Revised Common Lectionary (Semicontinuous)
Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti gittiti. Ti Asafu.
81 Kọrin sókè sí Ọlọ́run agbára wa
Ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọ́run Jakọbu!
10 Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ,
ẹni tí ó mú un yín jáde láti Ejibiti.
Ẹ la ẹnu yín gbòòrò, èmi yóò sì kún un.
11 “Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi kì yóò gbọ́ tèmi;
Israẹli kò ní tẹríba fún mi.
12 Nítorí náà ni mo ṣe fi wọ́n fún ọkàn líle wọn
láti máa rìn ní ọ̀nà ẹ̀tàn wọn.
13 “Bí àwọn ènìyàn mi yóò bá gbọ́ tèmi
bí Israẹli yóò bá tẹ̀lé ọ̀nà mi,
14 Ní kánkán ni èmi yóò ṣẹ́gun àwọn ọ̀tá wọn
kí n sì yí ọwọ́ mi padà sí ọ̀tá wọn!
15 Àwọn tí ó kórìíra Olúwa yóò tẹríba níwájú rẹ̀.
Ìjìyà wọn yóò sì pẹ́ títí láé
16 Ṣùgbọ́n a ó fi ọkà tí ó dára bọ́ ọ yín
èmi ó tẹ́ ẹ yín lọ́rùn pẹ̀lú oyin inú àpáta.”
Israẹli kọ Ọlọ́run sílẹ̀
2 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé: 2 “Lọ kí o sì kéde sí etí Jerusalẹmu pé:
“Báyìí ni Olúwa wí,
“ ‘Èmi rántí ìṣeun ìgbà èwe rẹ,
ìfẹ́ ìgbéyàwó rẹ
àti nígbà tí ìwọ tẹ̀lé mi nínú ijù,
nínú ìyàngbẹ ilẹ̀.
3 Israẹli jẹ́ mímọ́ sí Olúwa,
àkọ́kọ́ èso ìkórè rẹ̀,
gbogbo ẹnikẹ́ni tí ó jẹ run ni a ó dá lẹ́bi,
ibi yóò sì wá sí orí wọn,’ ”
bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí.
14 Israẹli ha á jẹ́ ọmọ ọ̀dọ̀
ẹrú nípa ìbí? Kí ló ha a
dé tí ó fi di ìkógun?
15 Àwọn kìnnìún ké ramúramù
wọ́n sì ń bú mọ́ wọn
wọ́n ti fi ilẹ̀ rẹ̀ ṣòfò
Ìlú rẹ̀ ti di jíjóná, ó sì
ti di ìkọ̀sílẹ̀.
16 Bákan náà, àwọn ọkùnrin
Memfisi àti Tafanesi
wọ́n ti fa adé orí rẹ yọ.
17 Ẹ̀yin kò ha a ti fa èyí sórí
ara yín nípa kíkọ Ọlọ́run sílẹ̀
nígbà tí ó tọ́ ọ lójú ọ̀nà?
18 Kí ló dé tí o ṣe wá lọ Ejibiti
láti lọ mu omi ní Ṣihori?
Kí ló dé tí o sì fi lọ sí Asiria
láti lọ mú omi ni odò Eufurate náà?
19 Iṣẹ́ búburú yín yóò fìyà jẹ yín
ìpadàsẹ́yìn rẹ yóò sì bá ọ wí
mọ̀ kí o sì rí i wí pé ibi àti
ohun búburú yóò sì jẹ́ tìrẹ
nígbà tí o ti kọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀,
ẹ kò sì ní ìbẹ̀rù fún mi,”
ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
20 “Nígbà àtijọ́, o ti fọ́ àjàgà
rẹ sọnù, ìwọ sì já ìdè rẹ
ìwọ wí pé, ‘Èmi kì yóò sìn ọ́!’
Lóòtítọ́, lórí gbogbo òkè gíga ni
àti lábẹ́ igi tí ó tànkálẹ̀
ni ìwọ dùbúlẹ̀ sí gẹ́gẹ́ bí panṣágà.
21 Èmi ti gbìn ọ́ gẹ́gẹ́ bí
àjàrà ọ̀tọ̀, gẹ́gẹ́ bí ìṣúra ọlọ́lá,
Báwo wá ni ìwọ ṣe yípadà sí mi
di àjàrà búburú àti aláìmọ́?
22 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o wẹ ara rẹ pẹ̀lú sódà
tí o sì lo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọṣẹ
síbẹ̀síbẹ̀ èérí ni ẹ̀ṣẹ̀ rẹ níwájú,”
ni Olúwa Olódùmarè wí.
Ẹ̀bẹ̀ ìyá
20 (A)(B) Nígbà náà ni ìyá àwọn ọmọ Sebede bá àwọn ọmọ rẹ̀ wá sọ́dọ̀ Jesu, ó wólẹ̀ lórí eékún rẹ̀, o béèrè fún ojúrere rẹ̀.
21 (C)Jesu béèrè pé, “Kí ni ìwọ ń fẹ́?”
Ó sì dáhùn pé, “Jẹ́ kí àwọn ọmọ mi méjèèjì jókòó ní apá ọ̀tún àti apá òsì lórí ìtẹ́ ìjọba rẹ?”
22 (D)Ṣùgbọ́n Jesu dáhùn ó sì wí pé, “Ẹ̀yin kò mọ ohun tí ẹ̀yin ń béèrè, ẹ̀yin ha le mu nínú ago tí èmi ó mu?”
Wọ́n dáhùn pé, “Àwa lè mu ún.”
23 (E)Jesu sì wí fún wọn pé, “Dájúdájú, ẹ̀yin yóò mu nínú ago mi, ṣùgbọ́n èmi kò ní àṣẹ láti sọ irú ènìyàn tí yóò jókòó ní apá ọ̀tún tàbí apá òsì. Baba mi ti pèsè ààyè wọ̀n-ọn-nì sílẹ̀ fún kìkì àwọn tí ó yàn.”
24 Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn mẹ́wàá ìyókù sì gbọ́ èyí, wọ́n bínú sí àwọn arákùnrin méjì yìí. 25 (F)Ṣùgbọ́n Jesu pé wọ́n papọ̀, ó wí pé, “Dájúdájú, ẹ̀yin mọ̀ pé àwọn ọba aláìkọlà a máa lo agbára lórí wọn, àwọn ẹni ńlá láàrín wọn a sì máa fi ọlá tẹrí àwọn tí ó wà lábẹ́ wọn ba. 26 Ṣùgbọ́n èyí yàtọ̀ láàrín yín. Dípò bẹ́ẹ̀, ẹni tí ó bá ń fẹ́ ṣe olórí láàrín yín, ní láti ṣe bí ìránṣẹ́ fún yín ni, 27 Àti ẹni tí ó bá fẹ́ ṣe olórí nínú yín, ẹ jẹ́ kí ó máa ṣe ọmọ ọ̀dọ̀ yin. 28 Gẹ́gẹ́ bí Ọmọ Ènìyàn kò ṣe wá sí ayé, kí ẹ lè ṣe ìránṣẹ́ fún un, ṣùgbọ́n láti ṣe ìránṣẹ́ fún yín, àti láti fi ẹ̀mí rẹ ṣe ìràpadà ọ̀pọ̀ ènìyàn.”
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.