Print Page Options
Previous Prev Day Next DayNext

Revised Common Lectionary (Semicontinuous)

Daily Bible readings that follow the church liturgical year, with sequential stories told across multiple weeks.
Duration: 1245 days
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Version
Saamu 107:1-9

ÌWÉ KARÙN-ÚN

Saamu 107–150

107 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun;
    nítorí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.

Jẹ́ kí àwọn ẹni ìràpadà Olúwa kí ó wí báyìí, àwọn
    ẹni tí ó rà padà kúrò lọ́wọ́ ọ̀tá,
Àwọn tí ó kójọ láti ilẹ̀ wọ̀n-ọn-nì
    láti ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn,
    láti àríwá àti Òkun wá.

Wọ́n ń rìn káàkiri ní aginjù ní ibi tí ọ̀nà kò sí,
    wọn kò rí ọ̀nà lọ sí ìlú níbi tí
    wọn ó máa gbé
Ebi ń pa wọn, òǹgbẹ gbẹ wọ́n,
    ó sì rẹ ọkàn wọn nínú wọn.
Ní ìgbà náà, wọ́n kígbe sókè
    Olúwa nínú ìdààmú wọn,
ó sì yọ wọ́n kúrò nínú ìrora wọn
Ó fi ọ̀nà títọ́ hàn wọ́n sí ìlú
    tí wọn lè máa gbé
Ẹ jẹ́ kí wọn máa yin Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́
    ìyanu rẹ̀ sí àwọn ọmọ ènìyàn,
Nítorí tí ó tẹ́ ìfẹ́ ọkàn lọ́run
    ó sì fi ìre fún ọkàn tí ebi ń pa.

Saamu 107:43

43 Ẹni tí ó bá gbọ́n, jẹ́ kí ó kíyèsi nǹkan wọ̀nyí
    kí ó wo títóbi ìfẹ́ Olúwa.

Hosea 9

Ìdájọ́ fún ẹsẹ̀ Israẹli

Má ṣe yọ̀, ìwọ Israẹli;
    má ṣe hó ìhó ayọ̀ bí àwọn orílẹ̀-èdè yòókù.
Nítorí ẹ ti jẹ́ aláìṣòótọ́ si Ọlọ́run yín.
    Ẹ fẹ́ràn láti gba owó iṣẹ́ àgbèrè
    ní gbogbo ilẹ̀ ìpakà.
Àwọn ilẹ̀ ìpakà àti ilé ìfun wáìnì kò ní fún àwọn ènìyàn lóúnjẹ
    wáìnì tuntun yóò tàn láìròtẹ́lẹ̀
Wọn kò ní ṣẹ́kù sí ilé Olúwa
    Efraimu yóò padà sí Ejibiti
    Yóò sì jẹ oúnjẹ àìmọ́ ní Asiria.
Wọn kò ní fi ọrẹ ohun mímu fún Olúwa.
    Bẹ́ẹ̀ ni ìrúbọ wọn kò ní mú, inú rẹ̀ dùn.
Ìrú ẹbọ bẹ́ẹ̀ yóò dàbí oúnjẹ àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀.
    Gbogbo àwọn tó bá sì jẹ ẹ́ yóò di aláìmọ́.
Oúnjẹ yìí yóò wà fún wọn fúnrawọn
    kò ní wá sí orí tẹmpili Olúwa.

Kí ni ẹ̀yin ó ṣe ní ọjọ́ àjọ̀dún tí a yàn
    ní àwọn ọjọ́ àjọ̀dún Olúwa?
Bí wọ́n tilẹ̀ yọ́ kúrò lọ́wọ́ ìparun
    Ejibiti yóò kó wọn jọ,
    Memfisi yóò sì sin wọ́n.
Ibi ìsọjọ̀ fàdákà wọn ni ẹ̀gún yóò jogún,
    Ẹ̀gún yóò bo àpótí ìṣúra fàdákà wọn.
Ẹ̀gún yóò sì bo
    gbogbo àgọ́ wọn.
(A)Àwọn ọjọ́ ìjìyà ń bọ̀;
    àwọn ọjọ́ ìṣirò iṣẹ́ ti dé
    Jẹ́ kí Israẹli mọ èyí
Nítorí pé ẹ̀ṣẹ̀ yín pọ̀
    ìkórìíra yín sì pọ̀ gan an ni.
A ka àwọn wòlíì sí òmùgọ̀
    A ka ẹni ìmísí sí asínwín.
Wòlíì, papọ̀ pẹ̀lú Ọlọ́run,
    ni olùṣọ́ ọ Efraimu.
Síbẹ̀ ìdẹ̀kùn dúró dè é ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀
    àti ìkórìíra ní ilé Ọlọ́run rẹ̀
Wọ́n ti gbilẹ̀ nínú ìwà ìbàjẹ́
    gẹ́gẹ́ bí i ọjọ́ Gibeah
Ọlọ́run yóò rántí ìwà búburú wọn
    yóò sì jẹ wọ́n ní yà fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn.

10 “Mo rí Israẹli bí èso àjàrà ní aginjù.
Mo rí àwọn baba yín,
    bí àkọ́pọ́n nínú igi ọ̀pọ̀tọ́ ní àkọ́so rẹ̀.
Ṣùgbọ́n wọ́n tọ Baali-Peori lọ,
    wọ́n yà wọn sọ́tọ̀ fún òrìṣà tó ń mú ìtìjú bá ni,
ohun ìríra wọn sì rí gẹ́gẹ́ bí wọn ti fẹ́. 11     Ògo Efraimu yóò fò lọ bí ẹyẹ
    kò ní sí ìfẹ́rakù, ìlóyún àti ìbímọ.
12 Bí wọ́n tilẹ̀ tọ́ ọmọ dàgbà.
    Èmi yóò mú wọn ṣọ̀fọ̀ lórí gbogbo wọn
Ègbé ni fún wọn,
    nígbà tí mo yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn!
13 Mo rí Efraimu bí ìlú Tire
    tí a tẹ̀dó sí ibi dáradára
ṣùgbọ́n Efraimu yóò kó àwọn
    ọmọ rẹ̀ jáde fún àwọn apànìyàn.”

14 Fún wọn, Olúwa!
    Kí ni ìwọ yóò fún wọn?
Fún wọn ní inú tí ń ba oyún jẹ́
    àti ọyàn gbígbẹ.

15 “Nítorí gbogbo ìwà búburú tí wọ́n hù ní Gilgali
    Mo kórìíra wọn níbẹ̀,
nítorí ìwà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
    Èmi yóò lé wọn jáde ní ilé mi
Èmi kò ní ní ìfẹ́ wọn mọ́
    ọlọ̀tẹ̀ ni gbogbo olórí wọn.
16 Efraimu ti rẹ̀ dànù
    gbogbo rẹ̀ sì ti rọ,
    kò sì so èso,
Bí wọ́n tilẹ̀ bímọ.
    Èmi ó pa àwọn ọmọ wọn tí wọ́n fẹ́ràn jùlọ.”

17 Ọlọ́run mi yóò kọ̀ wọ́n sílẹ̀
    nítorí pé wọn kò gbọ́rọ̀ sí i;
    wọn yóò sì di alárìnkiri láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.

Efesu 4:17-24

Gbígbé ìgbé ayé gẹ́gẹ́ bí ọmọ ìmọ́lẹ̀

17 Ǹjẹ́ èyí ni mo ń wí, tí mo sì ń jẹ́rìí nínú Olúwa pé, láti ìsinsin yìí lọ, kí ẹ̀yin má ṣe rìn mọ́, àní gẹ́gẹ́ bí àwọn aláìkọlà ti ń rìn nínú ìrònú asán wọn. 18 Òye àwọn ẹni tí ó ṣókùnkùn, a sì yà wọ́n nínú ìyè Ọlọ́run nítorí àìmọ̀ tí ń bẹ nínú wọn, nítorí líle ọkàn wọn. 19 Àwọn ẹni tí ọkàn wọn le rékọjá, tí wọ́n sì ti fi ara wọn fún wọ̀bìà, láti máa fi ìwọra ṣiṣẹ́ ìwà èérí gbogbo.

20 Ṣùgbọ́n a kò fi Kristi kọ́ yín bẹ́ẹ̀. 21 Bí ó bá ṣe pé nítòótọ́ ni ẹ ti gbóhùn rẹ̀ ti a sì ti kọ́ yín nínú rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí òtítọ́ ti ń bẹ nínú Jesu. 22 Pé, ní tì ìwà yín àtijọ́, kí ẹ̀yin bọ́ ògbólógbòó ọkùnrin nì sílẹ̀, èyí tí ó díbàjẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ẹ̀tàn; 23 Kí ẹ sì di tuntun ni ẹ̀mí inú yín; 24 kí ẹ sì gbé ọkùnrin tuntun ni wọ̀, èyí tí a dá ni àwòrán Ọlọ́run nínú òdodo àti ìwà mímọ́ ti òtítọ́.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)

Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.