Revised Common Lectionary (Semicontinuous)
Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti gittiti. Ti Asafu.
81 Kọrin sókè sí Ọlọ́run agbára wa
Ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọ́run Jakọbu!
10 Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ,
ẹni tí ó mú un yín jáde láti Ejibiti.
Ẹ la ẹnu yín gbòòrò, èmi yóò sì kún un.
11 “Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi kì yóò gbọ́ tèmi;
Israẹli kò ní tẹríba fún mi.
12 Nítorí náà ni mo ṣe fi wọ́n fún ọkàn líle wọn
láti máa rìn ní ọ̀nà ẹ̀tàn wọn.
13 “Bí àwọn ènìyàn mi yóò bá gbọ́ tèmi
bí Israẹli yóò bá tẹ̀lé ọ̀nà mi,
14 Ní kánkán ni èmi yóò ṣẹ́gun àwọn ọ̀tá wọn
kí n sì yí ọwọ́ mi padà sí ọ̀tá wọn!
15 Àwọn tí ó kórìíra Olúwa yóò tẹríba níwájú rẹ̀.
Ìjìyà wọn yóò sì pẹ́ títí láé
16 Ṣùgbọ́n a ó fi ọkà tí ó dára bọ́ ọ yín
èmi ó tẹ́ ẹ yín lọ́rùn pẹ̀lú oyin inú àpáta.”
Ọ̀rọ̀ Jeremiah
12 Olúwa, olódodo ni ọ́ nígbàkúgbà,
nígbà tí mo mú ẹjọ́ kan tọ̀ ọ́ wá.
Síbẹ̀ èmi yóò bá ọ sọ̀rọ̀ nípa òdodo rẹ.
Èéṣe tí ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú fi ń ṣe déédé?
Èéṣe tí gbogbo àwọn aláìṣòdodo sì ń gbé ní ìrọ̀rùn?
2 Ó ti gbìn wọ́n, wọ́n sì ti fi egbò múlẹ̀,
wọ́n dàgbà wọ́n sì so èso.
Gbogbo ìgbà ni ó wà ní ètè wọn,
o jìnnà sí ọkàn wọn.
3 Síbẹ̀ o mọ̀ mí ní Olúwa,
o ti rí mi o sì ti dán èrò mi nípa rẹ wò.
Wọ, wọ́n lọ bí àgùntàn tí a fẹ́ pa.
Yà wọ́n sọ́tọ̀ fún ọjọ́ pípa.
4 Yóò ti pẹ́ tó tí ọ̀gbẹlẹ̀ yóò fi wà,
tí gbogbo ewéko igbó sì ń rọ?
Nítorí àwọn ènìyàn búburú ni ó ń gbé ibẹ̀.
Àwọn ẹranko àti àwọn ẹyẹ ti ṣègbé,
pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn ènìyàn ń sọ pé,
“Kò lè rí ohun tó ṣẹlẹ̀ sí wa.”
Ìdáhùn Ọlọ́run
5 Bí ìwọ bá ń bá ẹlẹ́ṣẹ̀ sáré,
tí àárẹ̀ sì mú ọ,
báwo ni ìwọ yóò ṣe bá ẹṣin díje?
Bí ìwọ bá kọsẹ̀ ní ilẹ̀ àlàáfíà,
bí ìwọ bá ní ìgbẹ́kẹ̀lé,
kí ni ìwọ ó ṣe nínú ẹkùn odò Jordani?
6 Àwọn arákùnrin rẹ àti àwọn
ìdílé—
ti dà ọ́, kódà wọ́n ti kẹ̀yìn sí ọ
Wọ́n ti hó lé ọ lórí;
Má ṣe gbà wọ́n gbọ́
bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ń sọ̀rọ̀ rẹ dáradára.
7 Èmi yóò kọ ilé mi sílẹ̀,
èmi yóò fi ìní mi sílẹ̀.
Èmi yóò fi ẹni tí mo fẹ́
lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́.
8 Ogún mi ti rí sí mi
bí i kìnnìún nínú igbó.
Ó ń bú ramúramù mọ́ mi;
nítorí náà mo kórìíra rẹ̀.
9 Ogún mi kò ha ti rí sí mi
bí ẹyẹ kannakánná
tí àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ dòyì ka, tí wọ́n sì kọjú ìjà sí i?
Ẹ lọ, kí ẹ sì kó gbogbo ẹranko igbó jọ,
ẹ mú wọn wá jẹ.
10 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ olùṣọ́-àgùntàn ni yóò sì ba ọgbà àjàrà mi jẹ́,
tí wọn yóò sì tẹ oko mi mọ́lẹ̀;
Wọ́n ó sọ oko dídára mi di
ibi tí a ń da ìdọ̀tí sí.
11 A ó sọ ọ́ di aṣálẹ̀ ilẹ̀
tí kò wúlò níwájú mi,
gbogbo ilẹ̀ ni yóò di ahoro
nítorí kò sí ẹnìkankan tí yóò náání.
12 Gbogbo ibi gíga tí ó wà nínú aṣálẹ̀
ni àwọn apanirun ti gorí,
nítorí idà Olúwa yóò pa
láti ìkangun kìn-ín-ní dé ìkangun èkejì ilẹ̀ náà;
kò sí àlàáfíà fún gbogbo alààyè.
13 Àlìkámà ni wọn yóò gbìn, ṣùgbọ́n ẹ̀gún ni wọn yóò ká,
wọn yóò fi ara wọn ṣe wàhálà, ṣùgbọ́n òfo ni èrè wọn.
Kí ojú kí ó tì yín nítorí èrè yín,
nítorí ìbínú gbígbóná Olúwa.
7 Ṣùgbọ́n òpin ohun gbogbo kù sí dẹ̀dẹ̀; nítorí náà kí ẹ̀yin wà ní àìrékọjá, kí ẹ sì máa ṣọ́ra nínú àdúrà. 8 Ju gbogbo rẹ̀ lọ, ẹ ní ìfẹ́ tí ó gbóná láàrín ara yín: nítorí ìfẹ́ ni ń bo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ mọ́lẹ̀. 9 Ẹ máa ṣe ara yín ni àlejò láìsí ìkùnsínú. 10 Bí olúkúlùkù ti rí ẹ̀bùn gbà, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ máa ṣe ìpín fún ni rẹ̀ láàrín ara yín, bí ìríjú rere tí onírúurú oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run. 11 Bí ẹnikẹ́ni ba ń sọ̀rọ̀, kí o máa sọ bí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, bí ẹnikẹ́ni bá ń ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́, kí ó ṣe é bí agbára tí Ọlọ́run fi fún un, kí a lè máa yin Ọlọ́run lógo ní ohun gbogbo nípa Jesu Kristi, ẹni tí ògo àti ìjọba wà fún láé àti láéláé. Àmín.
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.