Print Page Options
Previous Prev Day Next DayNext

Old/New Testament

Each day includes a passage from both the Old Testament and New Testament.
Duration: 365 days
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Version
Orin Solomoni 4-5

Olùfẹ́

Báwo ni ìwọ ti lẹ́wà tó olólùfẹ́ mi!
    Háà, ìwọ jẹ́ arẹwà!
    Ìwọ ní ojú àdàbà lábẹ́ ìbòjú rẹ
irun rẹ bò ọ́ lójú bí ọ̀wọ́ ewúrẹ́.
    Tí ó sọ̀kalẹ̀ lórí òkè Gileadi.
Eyín rẹ̀ funfun bí i irun àgbò
    tí ó gòkè wá láti ibi ìwẹ̀;
olúkúlùkù wọn bí èjìrẹ́;
    kò sí ọ̀kan nínú wọn tí ó da dúró.
Ètè rẹ dàbí òwú òdòdó;
    ẹnu rẹ̀ dùn.
Ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ dàbí ẹ̀là pomegiranate
    lábẹ́ ìbòjú rẹ
Ọrùn rẹ dàbí ilé ìṣọ́ Dafidi,
    tí a kọ́ pẹ̀lú ìhámọ́ra;
lórí rẹ̀ ni a fi ẹgbẹ̀rún àpáta kọ́,
    gbogbo wọn jẹ́ àṣà àwọn alágbára.
Ọmú rẹ̀ méjèèjì dàbí abo egbin méjì
    tí wọ́n jẹ́ ìbejì
    tí ń jẹ láàrín ìtànná ewéko lílì.
Títí ọjọ́ yóò fi rọ̀
    tí òjìji yóò fi fò lọ,
Èmi yóò lọ sí orí òkè ńlá òjìá
    àti sí òkè kékeré tùràrí.
Gbogbo ara rẹ jẹ́ kìkì ẹwà, olólùfẹ́ mi;
    kò sì ṣí àbàwọ́n lára rẹ.

Kí a lọ kúrò ní Lebanoni, ìyàwó mi,
    ki a lọ kúrò ní Lebanoni.
Àwa wò láti orí òkè Amana,
    láti orí òkè ti Seniri, àti téńté Hermoni,
láti ibi ihò àwọn kìnnìún,
    láti orí òkè ńlá àwọn ẹkùn.
Ìwọ ti gba ọkàn mi, arábìnrin mi, ìyàwó mi;
    ìwọ ti gba ọkàn mi
pẹ̀lú ìwò ẹ̀ẹ̀kan ojú rẹ,
    pẹ̀lú ọ̀kan nínú ìlẹ̀kẹ̀ ọrùn rẹ,
10 Ìfẹ́ rẹ ti dùn tó, arábìnrin mi, ìyàwó mi!
    Ìfẹ́ rẹ tu ni lára ju ọtí wáìnì lọ,
    òórùn ìkunra rẹ sì ju òórùn gbogbo tùràrí lọ!
11 Ètè rẹ ń kan dídùn bí afárá oyin, ìyàwó mi;
    wàrà àti oyin wà lábẹ́ ahọ́n rẹ.
    Òórùn aṣọ rẹ sì dàbí òórùn Lebanoni.
12 Arábìnrin mi ni ọgbà tí a sọ, arábìnrin mi, ìyàwó mi
    ìsun tí a sé mọ́, orísun tí a fi èdìdì dì.
13 Ohun ọ̀gbìn rẹ àgbàlá pomegiranate ni
    ti òun ti àṣàyàn èso; kipiresi àti nadi,
14     Nadi àti Safironi,
    kalamusi àti kinamoni,
    àti gbogbo igi olóòórùn dídùn,
    òjìá àti aloe
    pẹ̀lú irú wọn.
15 Ìwọ ni ọgbà orísun, kànga omi ìyè,
    ìṣàn omi láti Lebanoni wá.

Olólùfẹ́

16 Jí ìwọ afẹ́fẹ́ àríwá
    kí o sì wá, afẹ́fẹ́ gúúsù!
Fẹ́ lórí ọgbà mi,
    kí àwọn òórùn dídùn inú rẹ lè rùn jáde.
Jẹ́ kí olùfẹ́ mi wá sínú ọgbà a rẹ̀
    kí ó sì jẹ àṣàyàn èso rẹ̀.

Olólùfẹ́

Mo ti dé inú ọgbà mi, arábìnrin mi, ìyàwó mi;
    mo ti kó òjìá pẹ̀lú òórùn dídùn mi jọ.
Mo ti jẹ afárá mi pẹ̀lú oyin mi;
    mo ti mu ọtí wáìnì mi pẹ̀lú wàrà mi.

Ọ̀rẹ́

Ẹ jẹ, ẹ̀yin ọ̀rẹ́, ẹ mu,
    àní ẹ mu àmuyó, ẹ̀yin olùfẹ́.

Olùfẹ́

Mo ti sùn ṣùgbọ́n ọkàn mi jí.
    Gbọ́! Olólùfẹ́ mi ń kan ìlẹ̀kùn.
“Ṣí i fún mi, arábìnrin mi, olùfẹ́ mi,
    àdàbà mi, aláìlábàwọ́n mi
Orí mi kún fún omi ìrì,
    irun mi kún fún òtútù òru.”
Mo ti bọ́ aṣọ ìgúnwà mi
    ṣé èmi gbọdọ̀ tún gbé e wọ̀?
Mo ti wẹ ẹsẹ̀ mi
    ṣé èmi gbọdọ̀ tún tì í bọ eruku?
Olùfẹ́ mi na ọwọ́ rẹ̀ láti inú ihò ìlẹ̀kùn
    inú mi sì yọ́ sí i
Èmi dìde láti ṣílẹ̀kùn fún olùfẹ́ mi,
    òjìá bẹ̀rẹ̀ sí í kán ní ọwọ́ mi,
òjìá olóòórùn ń ti ara ìka mi ń sàn
    sí orí ìdìmú ìlẹ̀kùn
Èmi ṣí ìlẹ̀kùn fún olùfẹ́ mi,
    ṣùgbọ́n olùfẹ́ mi ti kúrò, ó ti lọ
    ọkàn mi gbọgbẹ́ fún lílọ rẹ̀.
Mo wá a kiri ṣùgbọ́n, n kò rí i.
    Mo pè é ṣùgbọ́n, kò dáhùn
Àwọn olùṣọ́ tí ń ṣọ́ ìlú rí mi
    bí wọ́n ti ṣe ń rìn yí ìlú ká.
Wọ́n nà mí, wọ́n sá mi lọ́gbẹ́;
    wọ́n gba ìborùn mi lọ́wọ́ mi.
    Àwọn olùṣọ́ tí ń ṣọ́ odi!
Ẹ̀yin ọmọbìnrin Jerusalẹmu, mo bẹ̀ yín
    bí ẹ̀yin bá rí olùfẹ́ mi,
kí ni ẹ̀yin yóò wí fún un?
    Ẹ wí fún un pé àìsàn ìfẹ́ ń ṣe mi.

Ọ̀rẹ́

Kí ni olùfẹ́ rẹ fi dára ju àwọn tókù lọ,
    ìwọ arẹwà jùlọ láàrín àwọn obìnrin?
Kí ni olùfẹ́ rẹ fi dára ju àwọn tókù lọ
    tí ìwọ fi ń fi wá bú bẹ́ẹ̀?

Olùfẹ́

10 Olùfẹ́ mi ní ìtànṣán ó sì pọ́n
    ó ní ọlá ju ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá lọ.
11 Orí rẹ̀ rí bí i wúrà tí ó dára jùlọ
    ìdì irun rẹ̀ rí bí i imọ̀ ọ̀pẹ
    ó sì dúdú bí i ẹyẹ ìwò
12 Ojú rẹ̀ rí bí i ti àdàbà
    ní ẹ̀bá odò tí ń sàn,
tí a fi wàrà wẹ̀,
    tí ó jì, tí ó sì dákẹ́ rọ́rọ́
13 Ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀ rí bí ibùsùn tùràrí
    tí ó sun òórùn tùràrí dídùn
Ètè rẹ̀ rí bí i ìtànná lílì
    ó ń kán òjìá olóòórùn dídùn
14 Apá rẹ̀ rí bí i ọ̀pá wúrà,
    tí a to ohun ọ̀ṣọ́ sí yíká
Ara rẹ̀ rí bí i eyín erin dídán
    tí a fi safire ṣe lọ́ṣọ̀ọ́.
15 Ẹsẹ̀ rẹ̀ rí bí i òpó mábù
    tí a gbé ka ihò ìtẹ̀bọ̀ wúrà dáradára
Ìrísí rẹ̀ rí bí igi kedari Lebanoni,
    tí dídára rẹ̀ kò ní ẹgbẹ́.
16 Ẹnu rẹ̀ jẹ́ adùn fún ara rẹ̀
    ó wu ni pátápátá.
Háà! Ẹ̀yin ọmọbìnrin Jerusalẹmu,
    Èyí ni olùfẹ́ mi, èyí sì ni ọ̀rẹ́ mi.

Galatia 3

Ìgbàgbọ́ tàbí iṣẹ́ òfin

Ẹ̀yin aláìnírònú ará Galatia! Ta ní ha tàn yín jẹ, kí ẹ̀yin má ṣe gba òtítọ́ gbọ́? Ní ojú ẹni tí a fi Jesu Kristi hàn gbangba láàrín yín ni ẹni tí a kàn mọ́ àgbélébùú. Kìkì èyí ni mo fẹ́ béèrè lọ́wọ́ yín: Nípa iṣẹ́ òfin ni ẹ̀yin gba Ẹ̀mí bí, tàbí nípa ìgbọ́ràn pẹ̀lú ìgbàgbọ́? Báyìí ni ẹ̀yin ṣe jẹ òmùgọ̀ tó bí? Ẹ̀yin tí ó ti bẹ̀rẹ̀ ìgbé ayé ìgbàgbọ́ yín nípa ti Ẹ̀mí, ṣé a ti wá sọ yín di pípé nípa ti ara ni? Ẹ̀yin ha ti jìyà ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan wọ̀nyí lásán? Bí ó bá ṣe pé nítòótọ́ lásán ni. Ṣé Ọlọ́run fún yín ní Ẹ̀mí rẹ̀, tí ó sì ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín yín nítorí tí ẹ̀yin pa òfin mọ, tàbí nítorí ẹ ní ìgbàgbọ́ sí ohun tí ẹ gbọ́? (A)Gẹ́gẹ́ bí Abrahamu “Ó gba Ọlọ́run gbọ́, a sì kà á sí òdodo fún un.”

Ẹ jẹ́ kí ó yé é yín nígbà náà pé, àwọn ti ó gbàgbọ́, àwọn náà ní í ṣe ọmọ Abrahamu. (B)Bí ìwé mímọ́ sì tí wí tẹ́lẹ̀ pé, Ọlọ́run yóò dá aláìkọlà láre nípa ìgbàgbọ́, ó tí wàásù ìhìnrere ṣáájú fún Abrahamu, ó ń wí pé, “Nínú rẹ̀ ni a ó bùkún fún gbogbo orílẹ̀-èdè.” (C)Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni àwọn tí i ṣe tí ìgbàgbọ́ jẹ́ ẹni alábùkún fún pẹ̀lú Abrahamu olódodo.

10 (D)Nítorí pé iye àwọn tí ń bẹ ni ipa iṣẹ́ òfin ń bẹ lábẹ́ ègún: nítorí tí a tí kọ ọ́ pé, “Ìfibú ni olúkúlùkù ẹni tí kò dúró nínú ohun gbogbo tí a kọ sínú ìwé òfin láti máa ṣe wọ́n. 11 (E)Nítorí ó dánilójú pé, a kò dá ẹnikẹ́ni láre níwájú Ọlọ́run nípa iṣẹ́ òfin: nítorí pé, olódodo yóò yè nípa ìgbàgbọ́.” 12 (F)Òfin kì í sì í ṣe ti ìgbàgbọ́: ṣùgbọ́n “Ẹni tí ó ba ṣe, yóò yè nípa wọn.” 13 (G)Kristi ti rà wá padà kúrò lọ́wọ́ ègún òfin, ẹni tí a fi ṣe ègún fún wa: nítorí tí a ti kọ ọ́ pé, “Ìfibú ni olúkúlùkù ẹni tí a fi kọ́ sórí igi.” 14 Ó gbà wá là ki ìbùkún Abrahamu ba à lè wá sórí àwọn aláìkọlà nípa Kristi Jesu; kí àwa ba à lè gba ìlérí Ẹ̀mí nípa ìgbàgbọ́.

Òfin àti ìlérí

15 Ará, èmi ń sọ̀rọ̀ bí ènìyàn, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ènìyàn ti a ti fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀, kò sí ẹni tí ó lè sọ ọ́ di asán, tàbí tí ó lè fi kún un mọ́. 16 (H)Ǹjẹ́ fún Abrahamu àti fún irú-ọmọ rẹ̀ ni a ti ṣe àwọn ìlérí náà. Ìwé Mímọ́ kò ṣe wí pé, Fún àwọn irú-ọmọ rẹ̀, bí ẹni pé ọ̀pọ̀lọpọ̀; ṣùgbọ́n bí ẹni pé ọ̀kan ṣoṣo, àti fún irú-ọmọ rẹ̀, èyí tí í ṣe Kristi. 17 (I)Èyí tí mò ń wí ni pé: májẹ̀mú tí Ọlọ́run ti fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ níṣàájú, òfin ti ó dé lẹ́yìn ọgbọ̀n-lé-nírinwó ọdún kò lè sọ ọ́ di asán, kí ó sì mú ìlérí náà di aláìlágbára. 18 (J)Nítorí bí ogún náà bá dúró lórí ṣíṣe gẹ́gẹ́ bí í òfin kì í ṣe ti ìlérí mọ́: ṣùgbọ́n Ọlọ́run ti fi í fún Abrahamu nípa ìlérí.

19 (K)Ǹjẹ́ kí ha ni òfin? A fi kún un nítorí ìrékọjá títí irú-ọmọ tí a ti ṣe ìlérí fún yóò fi dé; a sì tipasẹ̀ àwọn angẹli ṣe ìlànà rẹ̀ láti ọwọ́ alárinà kan wá. 20 Ǹjẹ́ onílàjà kì í ṣe alárinà ti ẹnìkan, ṣùgbọ́n ọ̀kan ni Ọlọ́run.

21 (L)Nítorí náà òfin ha lòdì sí àwọn ìlérí Ọlọ́run bí? Kí a má rí i; Nítorí ìbá ṣe pé a ti fi òfin kan fún ni tí ó lágbára láti sọ ni di ààyè nítòótọ́ òdodo ìbá ti tipasẹ̀ òfin wà. 22 (M)Ṣùgbọ́n ìwé mímọ́ ti fi yé wa pé gbogbo ènìyàn ni ń bẹ lábẹ́ ìdè ẹ̀ṣẹ̀, kí a lè fi ìlérí nípa ìgbàgbọ́ nínú Jesu Kristi fún àwọn tí ó gbàgbọ́.

23 Ṣùgbọ́n kí ìgbàgbọ́ tó dé, a ti pa wá mọ́ lábẹ́ òfin, a sì sé wa mọ́ de ìgbàgbọ́ tí a ń bọ̀ wá fihàn. 24 Nítorí náà òfin ti jẹ́ olùtọ́jú láti mú ènìyàn wá sọ́dọ̀ Kristi, kí a lè dá wa láre nípa ìgbàgbọ́. 25 Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ìgbà tí ìgbàgbọ́ ti dé, àwa kò sí lábẹ́ olùtọ́jú mọ́.

Ọmọ Ọlọ́run

26 Nítorí pé ọmọ Ọlọ́run ni gbogbo yín, nípa ìgbàgbọ́ nínú Kristi Jesu. 27 Nítorí pé iye ẹ̀yin tí a ti bamitiisi sínú Kristi ti gbé Kristi wọ̀. 28 (N)Kò le sí Júù tàbí Giriki, ẹrú tàbí òmìnira, ọkùnrin tàbí obìnrin nítorí pé ọ̀kan ni nínú Kristi Jesu. 29 Bí ẹ̀yin bá sì jẹ́ ti Kristi, ǹjẹ́ ẹ̀yin ní irú-ọmọ Abrahamu, àti àrólé gẹ́gẹ́ bí ìlérí.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)

Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.