Old/New Testament
19 Ó sàn kí ènìyàn jẹ́ tálákà tí ìrìn rẹ̀ kò lábùkù ju aláìgbọ́n tí ètè rẹ̀ jẹ́ àyídáyidà.
2 Kò dára láti ní ìtara láìní ìmọ̀ tàbí kí ènìyàn kánjú kí ó sì ṣìnà.
3 Ìwà òmùgọ̀ ènìyàn fúnrarẹ̀ a pa ẹ̀mí rẹ̀ run;
síbẹ̀ ọkàn rẹ̀ yóò máa bínú sí Olúwa.
4 Ọrọ̀ máa ń fa ọ̀rẹ́ púpọ̀;
ṣùgbọ́n ọ̀rẹ́ tálákà tún kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
5 Ajẹ́rìí èké kò ní lọ láìjìyà, ẹni tí ó sì ń tú irọ́ jáde kò ní lọ lọ́fẹ̀ẹ́.
6 Ọ̀pọ̀ ń wá ojúrere olórí;
gbogbo ènìyàn sì ni ọ̀rẹ́ ẹni tí ó lawọ́.
7 Gbogbo ará ilé e tálákà ni ó pa á tì
mélòó mélòó ni ti àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ tí ń sá fún un!
Bí ó tilẹ̀ ń lé wọn kiri pẹ̀lú ẹ̀bẹ̀,
kò tilẹ̀ le rí wọn rárá.
8 Ẹni tí ó gba ọgbọ́n fẹ́ràn ọkàn ara rẹ̀;
ẹni tí ó bá káràmáṣìkí òye yóò gbèrú.
9 Ajẹ́rìí èké kì yóò lọ láìjìyà
ẹni tí ó sì ń tú irọ́ jáde yóò parun.
10 Kò yẹ aláìgbọ́n láti máa gbé nínú ọláńlá,
mélòó mélòó bí ó ti burú tó fún ẹrú láti jẹ ọba lórí ọmọ-aládé.
11 Ọgbọ́n ènìyàn a máa fún un ní sùúrù;
fún ògo rẹ̀ ni láti fojú fo àṣìṣe dá.
12 Ìbínú ọba dàbí kíké e kìnnìún,
ṣùgbọ́n ojúrere rẹ̀ dàbí ìrì lára koríko.
13 Aṣiwèrè ọmọ jẹ́ ìparun baba rẹ̀,
Aya tí ó máa ń jà sì dàbí ọ̀ṣọ̀ọ̀rọ̀ òjò.
14 A máa ń jogún ilé àti ọrọ̀ lọ́dọ̀ òbí
ṣùgbọ́n aya olóye láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni.
15 Ọ̀lẹ ṣíṣe máa ń fa oorun sísùn fọnfọn,
ebi yóò sì máa pa ènìyàn tí ó lọ́ra.
16 Ẹnikẹ́ni tí ó gbọ́ ẹ̀kọ́ pa ẹnu rẹ̀ mọ́
ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá kẹ́gàn ọ̀nà rẹ̀ yóò kú.
17 Ẹni tí ó ṣàánú tálákà, Olúwa ní ó yá
yóò sì pín in lérè ohun tí ó ti ṣe.
18 Bá ọmọ rẹ wí nítorí nínú ìyẹn ni ìrètí wà;
àìṣe bẹ́ẹ̀ ìwọ lọ́wọ́ nínú ìparun un rẹ̀.
19 Ènìyàn onínú-fùfù gbọdọ̀ gba èrè ìwà rẹ̀
bí ìwọ bá gbà á là, ìwọ yóò tún ní láti ṣe é lẹ́ẹ̀kan sí i.
20 Fetí sí ìmọ̀ràn kí o sì gba ẹ̀kọ́
ní ìgbẹ̀yìn gbẹ́yín ìwọ yóò di ọlọ́gbọ́n.
21 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ète inú ọkàn ènìyàn
ṣùgbọ́n ìfẹ́ Olúwa ní ó máa ń borí.
22 Ohun tí ènìyàn ń fẹ́ ni ìfẹ́ tí kì í yẹ̀;
ó sàn láti jẹ́ tálákà ju òpùrọ́ lọ.
23 Ìbẹ̀rù Olúwa ń mú ìyè wá:
nígbà náà ọkàn ń balẹ̀, láìsí ewu.
24 Ọ̀lẹ ki ọwọ́ rẹ̀ bọ inú àwo oúnjẹ;
kò tilẹ̀ ní mú u padà wá sí ẹnu rẹ̀.
25 Na ẹlẹ́gàn, òpè yóò sì kọ́gbọ́n;
bá olóye ènìyàn wí, yóò sì ní ìmọ̀ sí i.
26 Ẹni tí ó ṣìkà sí baba rẹ̀, tí ó sì lé ìyá rẹ̀ jáde
òun ni ọmọ tí ń ṣe ìtìjú, tí ó sì mú ẹ̀gàn wá.
27 Ọmọ mi, dẹ́kun láti tẹ́tí sí ẹ̀kọ́,
tí í mú ni ṣìnà kúrò nínú ọ̀rọ̀-ìmọ̀.
28 Ẹlẹ́rìí búburú fi ìdájọ́ ṣẹ̀sín,
ẹnu ènìyàn búburú sì ń gbé ibi mì.
29 A ti pèsè ìjìyà sílẹ̀ fún ẹlẹ́gàn;
àti pàṣán fún ẹ̀yìn àwọn aṣiwèrè.
20 Ẹlẹ́yà ni ọtí wáìnì, aláriwo sì ní ọtí líle
ẹnikẹ́ni tí ó bá fi tànjẹ kò gbọ́n.
2 Ìbẹ̀rù ọba dàbí kíké e kìnnìún;
ẹnikẹ́ni tí ó bá mú un bínú ba ayé ara rẹ̀ jẹ́.
3 Iyì ni ó jẹ́ fún ènìyàn láti sá fún ìjà,
ṣùgbọ́n gbogbo aláìgbọ́n a máa tètè wá ìjà.
4 Ọ̀lẹ kì í ṣiṣẹ́ oko nígbà tí ó yẹ,
nítorí náà ní àsìkò ìkórè, yóò wá kò sì ní rì nǹkan.
5 Ète ọkàn ènìyàn dàbí omi jíjìn;
ṣùgbọ́n ènìyàn olóye á wá wọn jáde.
6 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni wọ́n máa ń sọ pe àwọn ní ìfẹ́ àìṣẹ̀tàn,
ṣùgbọ́n kò rọrùn láti rí ènìyàn olóòtítọ́.
7 Olódodo ènìyàn a máa gbé ìgbé ayé àìlábùkù
ìbùkún ni fún àwọn ọmọ rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀.
8 Nígbà tí ọba bá jókòó sórí ìtẹ́ rẹ̀ láti ṣe ìdájọ́
yóò fẹ́ gbogbo ibi dànù pẹ̀lú ojú rẹ̀.
9 Ta ni ó le è wí pé, “Mo ti ṣe ọkàn mi ní mímọ́,
mo mọ́, n kò sì lẹ́ṣẹ̀”?
10 Ìwọ̀n èké àti òṣùwọ̀n ìrẹ́jẹ
Olúwa kórìíra méjèèjì.
11 Kódà a mọ ọmọdé nípa iṣẹ́ rẹ̀
nípa pe bóyá iṣẹ́ rẹ mọ́ tàbí pé ó tọ̀nà.
12 Etí tí ó ń gbọ́ àti ojú tí ó ń ríran
Olúwa ni ó dá méjèèjì.
13 Má ṣe fẹ́ràn oorun, àìṣe bẹ́ẹ̀ ìwọ yóò di tálákà.
Ma ṣe sùn ìwọ yóò sì ní oúnjẹ láti tún fi tọrọ.
14 “Kò dára, kò dára” ní ẹni tó ra ọjà máa ń wí
nígbà tí ó bá kúrò níbẹ̀ tán,
yóò máa yangàn bí òun tí ṣe rí rà sí.
15 Wúrà wà, iyùn sì wà rẹpẹtẹ
ṣùgbọ́n, ahọ́n tí ń sọ ìmọ̀ gan an ni ọ̀ṣọ́ iyebíye.
16 Gba abọ́ ẹni tí ó ṣe onídùúró fún àlejò;
mú un lọ́wọ́ bí ìbúra bí ó bá ṣe é fún obìnrin onírìnkurìn.
17 Oúnjẹ tí a fi ọ̀nà èrú rí máa ń dùn lẹ́nu ènìyàn
ṣùgbọ́n, a yọrí sí ibi ẹnu tí ó kún fún erùpẹ̀.
18 Pa ètè rẹ mọ́ nípa wíwá ìmọ̀ràn
bí o bá ń jagun, gba ìtọ́sọ́nà.
19 Olófòófó a máa tú àṣírí
nítorí náà yẹra fún ènìyàn tí ń rojọ́ púpọ̀.
20 Bí ènìyàn kan bá ṣépè fún baba tàbí ìyá rẹ̀,
ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ ni a ó pa kú nínú òkùnkùn biribiri.
21 Ogún tí a kójọ kíákíá ní ìbẹ̀rẹ̀
kì yóò ní ìbùkún ní ìgbẹ̀yìn gbẹ́yín.
22 Má ṣe wí pé, “N ó ṣẹ̀san àṣìṣe rẹ yìí fún ọ”
Dúró de Olúwa yóò sì gbà ọ́ là.
23 Olúwa kórìíra òdínwọ̀n èké.
Òṣùwọ̀n ìrẹ́jẹ kò sì tẹ́ ẹ lọ́rùn.
24 Olúwa ni ó ń ṣe olùdarí ìgbésẹ̀ ènìyàn
Báwo wá ni òye gbogbo ọ̀nà ènìyàn ṣe le yé ni?
25 Ìdẹ̀kùn ni fún ènìyàn láti ṣe ìlérí kíákíá
nígbà tí ó bá sì yá kí ó máa ro ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ wò.
26 Ọlọ́gbọ́n ọba tú ènìyàn búburú ká;
Ó sì fi òòlọ ìpakà lọ̀ wọ́n.
27 Àtùpà Olúwa ń ṣe àwárí ẹ̀mí ènìyàn
a máa ṣàwárí ibi ìkọ̀kọ̀ inú.
28 Ìfẹ́ àti òdodo pa ọba mọ́,
nípa ìfẹ́, ìtẹ́ rẹ̀ wà láìléwu.
29 Ògo àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin ni agbára wọn,
ewú orí ni iyì arúgbó.
30 Ìgbájú ìgbámú àti ìfarapa máa ń mú ibi lọ,
pàṣán sì máa ń ṣe àfọ̀mọ́ ibi ìkọ̀kọ̀ inú.
21 Ọkàn ọba ń bẹ lọ́wọ́ Olúwa;
a máa darí rẹ̀ lọ ibi tí ó fẹ́ bí ipa omi.
2 Gbogbo ọ̀nà ènìyàn dàbí i pé ó dára lójú rẹ̀
ṣùgbọ́n, Olúwa ló ń díwọ̀n ọkàn.
3 Ṣíṣe ohun tí ó dára tí ó sì tọ̀nà
ó ṣe ìtẹ́wọ́gbà sí Olúwa ju ẹbọ lọ.
4 Ojú tí ó gbéga àti ọkàn ìgbéraga,
ìmọ́lẹ̀ àwọn ènìyàn búburú, ẹ̀ṣẹ̀ ni!
5 Ètè àwọn olóye jásí èrè
bí ìkánjú ṣe máa ń fa òsì kíákíá.
6 Ìṣúra tí a kójọ nípasẹ̀ ahọ́n tí ń parọ́
jẹ́ ìrì lásán àti ìkẹ́kùn ikú.
7 Ìwà ipá àwọn ènìyàn búburú yóò wọ́ wọn lọ,
nítorí wọ́n kọ̀ láti ṣe ohun tí ó tọ́.
8 Ọ̀nà ẹlẹ́ṣẹ̀ kún fún ìwà ẹ̀ṣẹ̀
ṣùgbọ́n iṣẹ́ onínú funfun jẹ́ títọ́.
9 Ó sàn láti máa gbé ní kọ̀rọ̀ orí òrùlé
ju láti ṣe àjọpín ilé pẹ̀lú aya oníjà.
10 Ènìyàn búburú ń fẹ́ ibi
aládùúgbò rẹ̀ kì í rí àánú kankan gbà lọ́dọ̀ rẹ̀.
11 Nígbà tí a bá ń fìyà jẹ ẹlẹ́gàn,
òpè a máa kọ́gbọ́n,
nígbà tí a bá sì kọ́ ọlọ́gbọ́n yóò ní ìmọ̀.
12 Olódodo ṣàkíyèsí ilé ènìyàn búburú
ó sì mú ènìyàn búburú wá sí ìparun.
Ìṣúra ẹni tí o gbọ́n
13 Ẹnikẹ́ni tí ó bá ti di etí rẹ̀ sí igbe olùpọ́njú,
òun tìkára rẹ̀ yóò ké pẹ̀lú;
ṣùgbọ́n a kì yóò gbọ́.
14 Ọ̀rẹ́ ìkọ̀kọ̀, mú ìbínú kúrò:
àti owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti ibi ìkọ̀kọ̀ wá,
dẹ́kun ìbínú líle.
15 Ayọ̀ ni fún olódodo láti ṣe ìdájọ́:
ṣùgbọ́n ìparun ni fún àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.
16 Ẹni tí ó bá yà kúrò ní ọ̀nà òye,
yóò máa gbé inú ìjọ àwọn òkú.
17 Ẹni tí ó bá fẹ́ afẹ́, yóò di tálákà:
ẹni tí ó fẹ́ ọtí wáìnì pẹ̀lú òróró kò le lọ́rọ̀.
18 Ènìyàn búburú ni yóò ṣe owó ìràpadà fún olódodo,
àti olùrékọjá fún ẹni dídúró ṣinṣin.
19 Ó sàn láti jókòó ní aginjù ju pẹ̀lú
oníjà obìnrin àti òṣónú lọ.
20 Ìṣúra iyebíye àti òróró wà ní ibùgbé ọlọ́gbọ́n;
ṣùgbọ́n òmùgọ̀ ènìyàn n bà á jẹ́.
21 Ẹni tí ó bá tẹ̀lé òdodo àti àánú yóò rí ìyè,
òdodo, àti ọlá.
22 Ọlọ́gbọ́n gòkè odi ìlú àwọn alágbára,
ó sì bi ibi gíga agbára ìgbẹ́kẹ̀lé wọn ṣubú.
23 Ẹnikẹ́ni tí ó bá pa ẹnu àti ahọ́n rẹ̀ mọ́,
ó pa ọkàn rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ìyọnu.
24 Agbéraga àti alágídí ènìyàn ń gan orúkọ ara rẹ̀ nítorí ó ń hùwà nínú ìwà ìgbéraga rẹ̀,
àti nínú ìbínú púpọ̀púpọ̀.
25 Ẹlẹ́rìí èké yóò ṣègbé, àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ yóò parun láé;
nítorí tí ọwọ́ rẹ̀ kọ iṣẹ́ ṣíṣe.
26 Ó ń fi ìlara ṣe ojúkòkòrò ní gbogbo ọjọ́:
ṣùgbọ́n olódodo a máa fi fún ni kì í sì í dáwọ́ dúró.
27 Ẹbọ ènìyàn búburú, ìríra ni:
mélòó mélòó ni nígbà tí ó mú un wá pẹ̀lú èrò ìwà ibi?
28 Ẹlẹ́rìí èké yóò ṣègbé:
ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ ẹni tí ó gbọ́, yóò dúró.
29 Ènìyàn búburú mú ojú ara rẹ̀ le:
ṣùgbọ́n ẹni ìdúró ṣinṣin ni ó ń mú ọ̀nà rẹ̀ tọ́.
30 Kò sí ọgbọ́n, kò sí ìmòye,
tàbí ìmọ̀ràn tí ó le mókè níwájú Olúwa.
31 A ń múra ẹṣin sílẹ̀ de ọjọ́ ogun:
ṣùgbọ́n ìṣẹ́gun jẹ́ ti Olúwa.
7 Nítorí náà, ẹ̀yin olùfẹ́, bí a ti ní àwọn ìlérí wọ̀nyí, ẹ jẹ́ kí a wẹ ara wá mọ́ kúrò nínú gbogbo ẹ̀gbin ti ara àti ti ẹ̀mí, kí a sọ ìwà mímọ́ dí pípé nínú ìbẹ̀rù Ọlọ́run.
Ayọ̀ Paulu
2 (A)Ẹ gbà wá tọkàntọkàn; a kò fi ibi ṣe ẹnikẹ́ni, a kò ba ẹnikẹ́ni jẹ́, a kò rẹ́ ẹnikẹ́ni jẹ. 3 (B)Èmi kò sọ èyí láti dá a yín lẹ́bi; nítorí mo tí wí ṣáájú pé, ẹ̀yin wà nínú ọkàn wa kí a lè jùmọ̀ kú, àti kí a lè jùmọ̀ wà láààyè. 4 Mo ní ìgboyà ńlá láti bá yín sọ̀rọ̀; ìṣògo mí lórí yín pọ̀; mo kún fún ìtùnú, mo sì ń yọ̀ rékọjá nínú gbogbo ìpọ́njú wa.
5 (C)Nítorí pé nígbà tí àwa tilẹ̀ dé Makedonia, ara wá kò balẹ̀, ṣùgbọ́n a ń pọ́n wá lójú níhà gbogbo, ìjà ń bẹ lóde, ẹ̀rù ń bẹ nínú. 6 (D)Ṣùgbọ́n ẹni tí ń tu àwọn onírẹ̀lẹ̀ nínú, àní Ọlọ́run, ó tù wá nínú nípa dídé tí Titu dé; 7 Kì í sì i ṣe nípa dídé rẹ̀ nìkan ṣùgbọ́n nípa ìtùnú náà pẹ̀lú tí ẹ ti tù ú nínú, nígbà tí ó ròyìn fún wa ìfẹ́ àtọkànwá yín, ìbànújẹ́ yín, àti ìtara yín fún mi; bẹ́ẹ̀ ní mo sì túbọ̀ yọ̀.
8 (E)Nítorí pé, bí mo tilẹ̀ ba inú yín jẹ́ nípa ìwé tí mo kọ èmi kò kábámọ̀ mọ́, bí mo tilẹ̀ ti kábámọ̀ tẹ́lẹ̀ rí; nítorí tí mo wòye pé ìwé mi mú yín banújẹ́, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé fún ìgbà díẹ̀. 9 Èmi yọ̀ nísinsin yìí, kì í ṣe nítorí tí a mú inú yín bàjẹ́, ṣùgbọ́n nítorí tí a mú inú yín bàjẹ́ sí ìrònúpìwàdà: nítorí ti a mú inú yín bàjẹ́ bí ẹni ìwà-bí-Ọlọ́run, kí ẹ̀yin má ṣe ti ipasẹ̀ wa pàdánù ní ohunkóhun. 10 Nítorí pé ìbànújẹ́ ẹni ìwà-bí-Ọlọ́run a máa ṣiṣẹ́ ìrònúpìwàdà sí ìgbàlà tí kì í mú àbámọ̀ wá: ṣùgbọ́n ìbànújẹ́ ti ayé a máa ṣiṣẹ́ ikú. 11 Kíyèsi i, nítorí ohun kan náà yìí tí a mú yin banújẹ́ fún bí ẹni ìwà-bí-Ọlọ́run, irú ìmúraṣíṣẹ́ tí ó mú jáde nínú yín, wíwẹ ara yín mọ́ ńkọ́, ìbànújẹ́ ńkọ́, ìpayà ńkọ́, ìfojúṣọ́nà ńkọ́, ìtara ńkọ́, ìjẹ́ni-níyà ńkọ́. Nínú ohun ààmì kọ̀ọ̀kan yìí ni ẹ̀yin ti fi ara yín hàn bí aláìlẹ́bi nínú ọ̀ràn náà. 12 (F)Nítorí náà, bí mo tilẹ̀ tí kọ̀wé sí yín, èmi kò kọ ọ́ nítorí ẹni tí ó ṣe ohun búburú náà tàbí nítorí ẹni ti a fi ohun búburú náà ṣe, ṣùgbọ́n kí àníyàn yín nítorí wá lè farahàn níwájú Ọlọ́run. 13 Nítorí náà, a tí fi ìtùnú yín tù wá nínú.
Àti nínú ìtùnú wa, a yọ̀ gidigidi nítorí pé Titu ní ayọ̀, nítorí láti ọ̀dọ̀ gbogbo yín ni a ti tu ẹ̀mí rẹ̀ lára. 14 Bí mo tilẹ̀ ti lérí ohunkóhun fún ún nítorí yín, a kò dójútì mí; ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí àwa ti sọ ohun gbogbo fún yín ní òtítọ́, gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni ìlérí wá níwájú Titu sì jásí òtítọ́. 15 Ọkàn rẹ̀ sì fà gidigidi sí yín, bí òun ti ń rántí ìgbọ́ràn gbogbo yín, bí ẹ ti fi ìbẹ̀rù àti ìwárìrì tẹ́wọ́gbà á. 16 Mo yọ̀ nítorí pé ní ohun gbogbo, mo ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú yín.
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.