Print Page Options
Previous Prev Day Next DayNext

Old/New Testament

Each day includes a passage from both the Old Testament and New Testament.
Duration: 365 days
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Version
Òwe 10-12

Àwọn òwe Solomoni

10 Àwọn òwe Solomoni:

    ọlọ́gbọ́n ọmọ ń mú inú baba rẹ̀ dùn
    ṣùgbọ́n aṣiwèrè ọmọ ń ba inú ìyá rẹ̀ jẹ́.

Ìṣúra tí a kójọ nípa ìwà búburú kò ní èrè
    ṣùgbọ́n òdodo a máa gbani lọ́wọ́ ikú.

Olúwa kì í jẹ́ kí ebi máa pa olódodo
    ṣùgbọ́n ó ba ète àwọn ènìyàn búburú jẹ́.

Ọwọ́ tí ó lẹ máa ń sọ ènìyàn di tálákà,
    ṣùgbọ́n ọwọ́ tí ó múra ṣíṣẹ́ a máa sọ ni di ọlọ́rọ̀.

Ẹni tí ó kó irúgbìn jọ ní àsìkò òjò jẹ́ ọlọ́gbọ́n ọmọ,
    ṣùgbọ́n ẹni tí ó sùn ní àsìkò ìkórè jẹ́ adójútini ọmọ.

Ìbùkún ní ó máa ń kún orí olódodo
    ṣùgbọ́n ìwà ipá máa ń kún ẹnu ènìyàn búburú.

Ìrántí olódodo yóò jẹ́ ìbùkún
    ṣùgbọ́n orúkọ ènìyàn búburú yóò jẹrà.

Ẹni tí ó gbọ́n nínú ọkàn rẹ̀ máa ń gba àṣẹ,
    ṣùgbọ́n ètè wérewère yóò parun.

Ẹni tí ó ń rìn déédé, ń rìn láìléwu
    ṣùgbọ́n àṣírí ẹni tí ń rin ọ̀nà pálapàla yóò tú.

10 Ẹni tí ń ṣẹ́jú pàkòpàkò fún ibi ń fa àìbalẹ̀ ọkàn
    aláìgbọ́n tí ń ṣàròyé kiri yóò parun.

11 Ẹnu olódodo jẹ́ orísun ìyè
    ṣùgbọ́n ìwà ipá ni ó gba gbogbo ẹnu ènìyàn búburú.

12 Ìríra a máa dá ìjà sílẹ̀,
    ṣùgbọ́n ìfẹ́ a máa bo gbogbo àṣìṣe mọ́lẹ̀.

13 Ọgbọ́n ni a ń bá lẹ́nu àwọn olóye
    ṣùgbọ́n kùmọ̀ wà fún ẹ̀yìn àwọn aláìlóye.

14 Ọlọ́gbọ́n ènìyàn kó ìmọ̀ jọ
    ṣùgbọ́n ẹnu aláìgbọ́n a máa ṣokùnfà ìparun.

15 Ọrọ̀ àwọn olódodo ni ìlú olódi wọn,
    ṣùgbọ́n òsì ni ìparun aláìní.

16 Èrè olódodo ń mú ìyè wá fún wọn
    ṣùgbọ́n èrè ènìyàn búburú ń mú ìjìyà wá fún wọn.

17 Ẹni tí ó gbọ́ ìbáwí fi ọ̀nà sí ìyè hàn
    ṣùgbọ́n ẹni tí ó kọ ìbáwí mú àwọn mìíràn ṣìnà.

18 Ẹni tí ó pa ìkórìíra rẹ̀ mọ́ jẹ́ òpùrọ́
    ẹni tí ó sì ń ba ni jẹ́ jẹ́ aláìgbọ́n.

19 Nínú ọ̀rọ̀ púpọ̀ a kò le fẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ kù
    ṣùgbọ́n ẹni tí ó pa ẹnu rẹ̀ mọ́ jẹ́ ọlọ́gbọ́n.

20 Ètè olódodo jẹ́ ààyò fàdákà
    ṣùgbọ́n ọkàn ènìyàn búburú kò níye lórí.

21 Ètè olódodo ń bọ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀
    ṣùgbọ́n aláìgbọ́n ń kú nítorí àìlóye.

22 Ìbùkún Olúwa ń mú ọrọ̀ wá,
    kì í sì í fi ìdààmú sí i.

23 Aláìgbọ́n a máa ní inú dídùn sí ìwà búburú
    ṣùgbọ́n olóye ènìyàn a máa ní inú dídùn sí ọgbọ́n.

24 Ohun tí ènìyàn búburú bẹ̀rù yóò dé bá a;
    Olódodo yóò rí ohun tí ó fẹ́ gbà.

25 Nígbà tí ìjì bá ti jà kọjá, ènìyàn búburú a kọjá lọ,
    ṣùgbọ́n Olódodo yóò dúró ṣinṣin láéláé.

26 Bí ọtí kíkan sí eyín, àti èéfín sí ojú
    bẹ́ẹ̀ ni ọ̀lẹ sí ẹni tí ó rán an níṣẹ́.

27 Ìbẹ̀rù Olúwa ń mú ọjọ́ ayé gígùn wá,
    ṣùgbọ́n a gé ọjọ́ ayé ènìyàn búburú kúrú.

28 Ìrètí olódodo ni ayọ̀
    ṣùgbọ́n ìrètí ènìyàn búburú jásí òfo.

29 Ọ̀nà Olúwa jẹ́ ààbò fún olódodo,
    ṣùgbọ́n ìparun ni ó jẹ́ fún àwọn tí ń ṣe ibi.

30 A kì yóò fa olódodo tu láéláé
    ṣùgbọ́n ènìyàn búburú kì yóò dúró pẹ́ lórí ilẹ̀.

31 Ẹnu olódodo ń mú ọgbọ́n jáde wá,
    ṣùgbọ́n ètè àyípadà ni a ó gé kúrò.

32 Ètè olódodo mọ ohun ìtẹ́wọ́gbà,
    ṣùgbọ́n ètè ènìyàn búburú kò mọ̀ ju èké lọ.

11 Olúwa kórìíra òṣùwọ̀n èké,
    ṣùgbọ́n òṣùwọ̀n òtítọ́ jẹ́ inú dídùn un rẹ̀.

Nígbà tí ìgbéraga bá dé, nígbà náà ni ìdójútì dé
    ṣùgbọ́n, pẹ̀lú ìrẹ̀lẹ̀ ni ọgbọ́n ń wá.

Òtítọ́ inú ẹni dídúró ṣinṣin ń ṣe amọ̀nà rẹ̀
    ṣùgbọ́n aláìṣòótọ́ yóò parun nípasẹ̀ àìṣòótọ́ wọn.

Ọ̀rọ̀ kò níláárí ní ọjọ́ ìbínú
    ṣùgbọ́n òdodo a máa gbani lọ́wọ́ ikú.

Òdodo aláìlẹ́gàn ṣe ọ̀nà tààrà fún wọn
    ṣùgbọ́n ìwà búburú ènìyàn búburú yóò fà á lulẹ̀.

Òdodo ẹni ìdúró ṣinṣin gbà wọ́n là
    ṣùgbọ́n ìdẹ̀kùn ètè búburú mú aláìṣòótọ́.

Nígbà tí ènìyàn búburú bá kú, ìrètí rẹ̀ a parun
    gbogbo ohun tó ń fojú ṣọ́nà fún nípa agbára rẹ̀ já ṣófo.

A gba olódodo kúrò lọ́wọ́ ibi
    dípò o rẹ̀, ibi wá sórí ènìyàn búburú.

Aláìmọ Ọlọ́run fi ẹnu rẹ̀ ba aládùúgbò rẹ̀ jẹ́,
    ṣùgbọ́n nípasẹ̀ ìmọ̀ olódodo sá àsálà.

10 Nígbà tí olódodo ń gbèrú, ìlú a yọ̀
    nígbà tí ènìyàn búburú parun, ariwo ayọ̀ gba ìlú kan.

11 Nípasẹ̀ ìbùkún, olódodo a gbé ìlú ga:
    ṣùgbọ́n nípasẹ̀ ẹnu ènìyàn búburú, a pa ìlú run.

12 Ẹni tí kò gbọ́n fojú kékeré wo aládùúgbò rẹ̀
    ṣùgbọ́n ẹni tí ó ní òye pa ẹnu rẹ̀ mọ́.

13 Olófòófó tú àṣírí ìkọ̀kọ̀
    ṣùgbọ́n ẹni tó ṣe é gbẹ́kẹ̀lé a pa àṣírí mọ́.

14 Nítorí àìní ìtọ́sọ́nà orílẹ̀-èdè ṣubú
    ṣùgbọ́n nípasẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ olùbádámọ̀ràn ìṣẹ́gun dájú.

15 Ẹni tí ó ṣe onígbọ̀wọ́ fún àlejò yóò rí ìyọnu,
    ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó kọ̀ láti ṣe onígbọ̀wọ́ yóò wà láìléwu.

16 Obìnrin oníwà rere gba ìyìn
    ṣùgbọ́n alágbára aláìbìkítà ènìyàn gba ọrọ̀ nìkan.

17 Ènìyàn rere ń ṣe ara rẹ̀ lóore
    ṣùgbọ́n ènìyàn ìkà ń mú ìyọnu wá sórí ara rẹ̀.

18 Ènìyàn búburú gba èrè ìtànjẹ
    ṣùgbọ́n ẹni tó fúnrúgbìn òdodo yóò gba èrè tó dájú.

19 Olódodo tòótọ́ rí ìyè
    ṣùgbọ́n ẹni tí ń lépa ibi lé e sí ibi ikú ara rẹ̀.

20 Olúwa kórìíra àwọn ènìyàn ọlọ́kàn búburú
    ṣùgbọ́n ó ní inú dídùn sí àwọn tí ọ̀nà wọn kò lábùkù.

21 Mọ èyí dájú pé: ènìyàn búburú kì yóò lọ láìjìyà,
    ṣùgbọ́n àwọn olódodo yóò lọ láìjìyà.

22 Bí òrùka wúrà ní imú ẹlẹ́dẹ̀
    ni arẹwà obìnrin tí kò lọ́gbọ́n.

23 Ìfẹ́ inú olódodo yóò yọrí sí ohun rere
    ṣùgbọ́n ìrètí ènìyàn búburú yóò yọrí sí ìbínú.

24 Ènìyàn kan ń fún ni lọ́fẹ̀ẹ́, síbẹ̀ ó ń ní sí i;
    òmíràn ń háwọ́ ju bí ó ti yẹ ṣùgbọ́n ó di aláìní.

25 Ẹni tí ń ṣoore yóò máa gbèrú sí i;
    ẹni tí ó tu ẹlòmíràn lára yóò ní ìtura.

26 Àwọn ènìyàn a ṣẹ́ èpè lé ènìyàn tí ń kó oúnjẹ pamọ́
    ṣùgbọ́n ìbùkún a máa wá sórí ẹni tí ó ṣetán láti tà.

27 Ẹni tí ń lépa ohun rere yóò rí ohun rere
    ṣùgbọ́n ibi yóò dé bá ẹni tí ń lépa ibi.

28 Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ rẹ̀ yóò ṣubú;
    ṣùgbọ́n olódodo yóò gbilẹ̀ bí i koríko tútù.

29 Ẹni tí ó ń mú ìdààmú dé bá ìdílé rẹ̀ yóò jogún afẹ́fẹ́ lásán
    aláìgbọ́n yóò sì máa ṣe ìránṣẹ́ fún ọlọ́gbọ́n.

30 Èso òdodo ni igi ìyè
    ẹni tí ó sì jèrè ọkàn jẹ́ ọlọ́gbọ́n.

31 (A)Bí àwọn olódodo bá gba ìpín wọn lórí ilẹ̀ ayé
    mélòó mélòó ni ènìyàn búburú àti àwọn tó dẹ́ṣẹ̀!

12 Ẹnikẹ́ni tí ó fẹ́ ẹ̀kọ́ fẹ́ ìmọ̀,
    ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó kórìíra ìbáwí jẹ́ aláìgbọ́n.

Ènìyàn rere gba ojúrere lọ́dọ̀ Olúwa
    ṣùgbọ́n ènìyàn ètè búburú ni yóò dá lẹ́bi.

A kò lè fi ẹsẹ̀ ènìyàn múlẹ̀ nípa ìwà búburú
    ṣùgbọ́n a kò le è fa olódodo tu.

Aya oníwà rere ni adé ọkọ rẹ̀
    ṣùgbọ́n aya adójútini dàbí inú egungun rẹ̀ jẹrà.

Èrò àwọn olódodo tọ́,
    ṣùgbọ́n ìgbìmọ̀ ènìyàn búburú jẹ́ ẹ̀tàn.

Ọ̀rọ̀ ènìyàn búburú lúgọ de ẹ̀jẹ̀
    ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ àwọn Olódodo gbà wọ́n là.

A ṣí àwọn ènìyàn búburú ní ìdí, wọn kò sì sí mọ́;
    ṣùgbọ́n ilé olódodo dúró ṣinṣin.

A ń yín ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀n ọgbọ́n rẹ̀
    ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn ọlọ́pọlọ wúruwùru ni a kẹ́gàn.

Ó sàn kí a má jẹ́ ènìyàn pàtàkì kí a sì ní ìránṣẹ́
    ju kí a díbọ́n pé a jẹ́ ẹni pàtàkì láìní oúnjẹ.

10 Olódodo ènìyàn ń ṣe aájò ohun tí àwọn ohun ọ̀sìn rẹ̀ nílò,
    ṣùgbọ́n ìyọ́nú àwọn ènìyàn búburú, ìkà ni.

11 Ẹni tí ó bá dá oko yóò ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ oúnjẹ,
    ṣùgbọ́n ẹni tí ń lépa òjìji lásán làsàn kò gbọ́n.

12 Ènìyàn búburú ń fẹ́ ìkógun àwọn ènìyàn ìkà
    ṣùgbọ́n gbòǹgbò olódodo ń gbilẹ̀.

13 A mú ènìyàn búburú nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀
    ṣùgbọ́n olódodo bọ́ kúrò lọ́wọ́ ìdààmú.

14 Láti inú èso rẹ̀, ènìyàn kún fún onírúurú ohun rere
    bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ti ń pín in lérè dájúdájú.

15 Ọ̀nà aláìgbọ́n dára lójú ara rẹ̀
    ṣùgbọ́n ọlọ́gbọ́n ènìyàn a máa gba ìmọ̀ràn.

16 Aláìgbọ́n ènìyàn fi ìbínú un rẹ̀ hàn lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀,
    ṣùgbọ́n olóye ènìyàn fojú fo ìyànjẹ.

17 Ẹni tí ó jẹ́ ajẹ́rìí òtítọ́ jẹ́rìí ohun tí ojú rẹ̀ rí
    ṣùgbọ́n ajẹ́rìí èké máa ń parọ́.

18 Ọ̀rọ̀ tí a kò rò jinlẹ̀ máa ń gún ni bí ọ̀kọ̀
    ṣùgbọ́n ahọ́n ọlọ́gbọ́n ń mú ìwòsàn wá.

19 Ètè tí ń ṣọ òtítọ́ yóò wà láéláé
    ṣùgbọ́n ahọ́n tí ń parọ́ kì í tọ́jọ́.

20 Ẹ̀tàn wà nínú ọkàn àwọn tí ń pète búburú
    ṣùgbọ́n ayọ̀ wà fún àwọn tí ń mú kí àlàáfíà gbilẹ̀.

21 Ibi kì í ṣubú lu olódodo rárá
    ṣùgbọ́n ènìyàn búburú gba ìpín ìyọnu tiwọn.

22 Olúwa kórìíra ètè tí ń parọ́
    ṣùgbọ́n ó ní inú dídùn sí àwọn olóòtítọ́.

23 Ènìyàn olóye fi ìmọ̀ rẹ̀ pamọ́ sínú ara rẹ̀
    ṣùgbọ́n ọkàn ènìyàn búburú ń gbé ìwà òmùgọ̀ jáde.

24 Ọwọ́ àìṣọ̀lẹ yóò jẹ ọba
    ṣùgbọ́n ọ̀lẹ ṣíṣe a máa yọrí sí ẹrú ṣíṣe.

25 Ìbànújẹ́ ní ọkàn ènìyàn ní dorí rẹ̀ kodò
    ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ rere a máa mú kó yọ̀.

26 Olódodo ènìyàn máa ń ṣọ́ra láti dọ́rẹ̀ẹ́
    ṣùgbọ́n ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú ń mú wọn ṣìnà.

27 Ọ̀lẹ ènìyàn kò sun ẹran tí ó pa lóko ọdẹ
    ṣùgbọ́n ẹni tí kì í ṣe ọ̀lẹ máa ń díwọ̀n ohun ìní rẹ̀.

28 Ní ọ̀nà àwọn olódodo ni ìyè wà
    ní ọ̀nà náà ni àìkú wà.

2 Kọrinti 4

Ìṣúra nínú ohun-èlò amọ̀

Nítorí náà, níwọ̀n bí ó ti jẹ́ pé nípa àánú Ọlọ́run ni a rí iṣẹ́ ìránṣẹ́ yìí gba, àárẹ̀ kò mú ọkàn wa rara; Ṣùgbọ́n àwa tí kọ gbogbo ohun ìkọ̀kọ̀ tí ó ní ìtìjú sílẹ̀, àwa kò rìn ní ẹ̀tàn, bẹ́ẹ̀ ni àwa kò fi ọwọ́ ẹ̀tàn mú ọ̀rọ̀ Ọlọ́run; ṣùgbọ́n nípa fífi òtítọ́ hàn, àwa ń fi ara wa le ẹ̀rí ọkàn olúkúlùkù ènìyàn lọ́wọ́ níwájú Ọlọ́run. Ṣùgbọ́n báyìí, bí Ìhìnrere wa bá sí fi ara sin, ó fi ara sin fún àwọn tí ó ń ṣègbé. (A)Nínú àwọn ẹni tí ọlọ́run ayé yìí ti sọ ọkàn àwọn aláìgbàgbọ́ dí afọ́jú, kí ìmọ́lẹ̀ ìhìnrere Kristi tí ó lógo, ẹni tí í ṣe àwòrán Ọlọ́run, má ṣe mọ́lẹ̀ nínú wọn. Nítorí àwa kò wàásù àwa tìkára wa, bí kò ṣe Kristi Jesu Olúwa; àwa tìkára wa sì jẹ́ ẹrú yín nítorí Jesu. (B)Nítorí Ọlọ́run ni ẹni tí ó wí pé, “Kí ìmọ́lẹ̀ ó tan láti inú òkùnkùn jáde,” òun ní ó ti ń tan mọ́lẹ̀ lọ́kàn wa, láti fún wa ní ìmọ́lẹ̀ ìmọ̀ ògo Ọlọ́run ní ojú Jesu Kristi.

Ṣùgbọ́n àwa ní ìṣúra yìí nínú ohun èlò amọ̀, kí ọláńlá agbára náà lè jẹ́ ti Ọlọ́run, kí ó má ṣe ti ọ̀dọ̀ wa wá. A ń pọ́n wa lójú níhà gbogbo, ṣùgbọ́n ara kò ni wá: a ń dààmú wa, ṣùgbọ́n a kò sọ ìrètí nù. A ń ṣe inúnibíni sí wa, ṣùgbọ́n a kò kọ̀ wá sílẹ̀; a ń rẹ̀ wá sílẹ̀ ṣùgbọ́n a kò pa wá run. 10 Nígbà gbogbo àwa ń ru ikú Jesu Olúwa kiri ni ará wa, kí a lè fi ìyè Jesu hàn pẹ̀lú lára wa. 11 Nítorí pé nígbà gbogbo ní a ń fi àwa tí ó wà láààyè fún ikú nítorí Jesu, kí a lè fi ìyè hàn nínú ara kíkú wa pẹ̀lú. 12 Bẹ́ẹ̀ ni ikú ń ṣiṣẹ́ nínú wa, ṣùgbọ́n ìyè ṣiṣẹ́ nínú yín.

13 (C)Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ́ pé, “Èmi gbàgbọ́, nítorí náà ni èmi ṣe sọ,” pẹ̀lú ẹ̀mí ìgbàgbọ́ kan náà, a tún gbàgbọ́ àti nítorí náà ni àwa sì ṣe ń sọ. 14 (D)Àwa mọ̀ pé, ẹni tí o jí Jesu Olúwa dìde yóò sì jí wa dìde pẹ̀lú nípa Jesu, yóò sì mú wa wà níwájú rẹ̀ pẹ̀lú yín 15 Nítorí tiyín ní gbogbo rẹ̀, ki ọ̀pẹ lè dí púpọ̀ fún ògo Ọlọ́run gẹ́gẹ́ bí oore-ọ̀fẹ́ ti ń gbòòrò sí i fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn.

16 Nítorí èyí ni àárẹ̀ kò ṣe mú wa; ṣùgbọ́n bí ọkùnrin ti òde wa bá ń parun, síbẹ̀ ọkùnrin tí inú wa ń di tuntun lójoojúmọ́. 17 Nítorí ìpọ́njú díẹ̀ yìí ń pèsè ògo tí ó ní ìwọ̀n ayérayé tí ó pọ̀ rékọjá sílẹ̀ fún wa. 18 Níwọ́n bí kò ti wo ohun tí a ń rí, bí kò ṣé ohun tí a kò rí; nítorí ohun tí a ń rí ni ti ìgbà ìsinsin yìí; ṣùgbọ́n ohun tí a kò rí ni ti ayérayé.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)

Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.