Old/New Testament
Ìdáhùn Sofari
20 Ìgbà náà ní Sofari, ará Naama dáhùn, ó sì wí pé:
2 “Nítorí náà ní ìrò inú mi dá mi lóhùn,
àti nítorí èyí náà ní mo sì yára si gidigidi.
3 Mo ti gbọ́ ẹ̀san ẹ̀gàn mi, ẹ̀mí òye
mi sì dá mi lóhùn.
4 “Ìwọ kò mọ̀ èyí rí ní ìgbà àtijọ́,
láti ìgbà tí a sọ ènìyàn lọ́jọ̀ sílé ayé,
5 pé, orin ayọ̀ ènìyàn búburú, ìgbà kúkúrú ni,
àti pé, ní ìṣẹ́jú kan ní ayọ̀ àgàbàgebè?
6 Bí ọláńlá rẹ̀ tilẹ̀ gòkè dé ọ̀run,
ti orí rẹ̀ sì kan àwọsánmọ̀;
7 Ṣùgbọ́n yóò ṣègbé láéláé bí ìgbẹ́ ara rẹ̀;
àwọn tí ó ti rí i rí yóò wí pé, ‘Òun ha dà?’
8 Yóò fò lọ bí àlá, a kì yóò sì rí i,
àní a ó lé e lọ bi ìran òru.
9 Ojú tí ó ti rí i rí kì yóò sì rí i mọ́,
bẹ́ẹ̀ ni ibùjókòó rẹ̀ kì yóò sì ri i mọ́.
10 Àwọn ọmọ rẹ̀ yóò máa wá àti rí ojúrere lọ́dọ̀ tálákà,
ọwọ́ rẹ̀ yóò sì kó ọrọ̀ wọn padà.
11 Egungun rẹ̀ kún fún agbára ìgbà èwe rẹ̀,
tí yóò bá a dùbúlẹ̀ nínú erùpẹ̀.
12 “Bí ìwà búburú tilẹ̀ dún ní ẹnu rẹ̀,
bí ó tilẹ̀ pa á mọ́ nísàlẹ̀ ahọ́n rẹ̀,
13 bí ó tilẹ̀ dá a sì, tí kò si kọ̀ ọ́ sílẹ̀,
tí ó pa á mọ́ síbẹ̀ ní ẹnu rẹ̀,
14 Ṣùgbọ́n oúnjẹ rẹ̀ nínú ikùn rẹ̀ ti yípadà,
ó jásí òróró paramọ́lẹ̀ nínú rẹ̀;
15 Ó ti gbé ọrọ̀ mì, yóò sì tún bí i jáde;
Ọlọ́run yóò pọ̀ ọ́ yọ jáde láti inú rẹ̀ wá.
16 Ó ti fà oró paramọ́lẹ̀ mú;
ahọ́n ejò olóró ní yóò pa á.
17 Kì yóò rí odò wọ̀n-ọn-nì,
ìṣàn omi, odò tí ń ṣàn fún oyin àti ti òrí-àmọ́.
18 Ohun tí ó ṣiṣẹ́ fún ni yóò mú un padà, kí yóò sì gbé e mì;
gẹ́gẹ́ bí ọrọ̀ tí ó ní, kì yóò sì ìgbádùn nínú rẹ̀.
19 Nítorí tí ó fi owó rẹ̀ ni tálákà lára, ó sì ti kẹ́hìndà wọ́n;
Nítorí ti ó fi agbára gbé ilé tí òun kò kọ́.
20 “Nítorí òun kò mọ̀ ìwà pẹ̀lẹ́ nínú ara rẹ̀,
kì yóò sì gbà nínú èyí tí ọkàn rẹ̀ fẹ́ sílẹ̀.
21 Ohun kan kò kù fún jíjẹ́ rẹ̀;
Nítorí náà ọ̀rọ̀ rẹ̀ kì yóò dúró pẹ́.
22 Nínú ànító rẹ̀, ìdààmú yóò dé bá a;
àwọn ènìyàn búburú yóò dáwọ́jọ lé e lórí.
23 Yóò sì ṣe, nígbà tí ó bá fẹ́ jẹun,
Ọlọ́run yóò fà ríru ìbínú rẹ̀ sí í lórí, nígbà tó bá ń jẹun lọ́wọ́,
yóò sì rọ òjò ìbínú rẹ̀ lé e lórí.
24 Bi o tilẹ̀ sá kúrò lọ́wọ́ ohun ìjà ìrìn;
ọrun akọ irin ní yóò ta a po yọ.
25 O fà á yọ, ó sì jáde kúrò lára;
idà dídán ní ń jáde láti inú òróòro wá.
Ẹ̀rù ńlá ń bẹ ní ara rẹ̀;
26 òkùnkùn biribiri ní a ti pamọ́ fún ìṣúra rẹ̀.
Iná ti a kò fẹ́ ní yóò jó o run
yóò sì jẹ èyí tí ó kù nínú àgọ́ rẹ̀ run.
27 Ọ̀run yóò fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ hàn,
ayé yóò sì dìde dúró sí i.
28 Ìbísí ilé rẹ̀ yóò kọjá lọ, àti ohun
ìní rẹ̀ yóò sàn dànù lọ ni ọjọ́ ìbínú Ọlọ́run.
29 Èyí ni ìpín ènìyàn búburú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá,
àti ogún tí a yàn sílẹ̀ fún un láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”
Jobu dá Sofari lóhùn
21 Jobu wá dáhùn, ó sì wí pé:
2 “Ẹ tẹ́tí sílẹ̀ dáradára sì àwọn ọ̀rọ̀ mi,
kí èyí kí ó jásí ìtùnú fún mi.
3 Ẹ jọ̀wọ́ mi ki èmi sọ̀rọ̀; lẹ́yìn ìgbà
ìwọ le máa fi mi ṣẹ̀sín ń ṣo.
4 “Àròyé mi ha ṣe sí ènìyàn bí?
Èétise tí ọkàn mi kì yóò fi ṣe àìbalẹ̀?
5 Ẹ wò mí fín, kí ẹnu kí ó sì yà yín,
kí ẹ sì fi ọwọ́ lé ẹnu yín.
6 Àní nígbà tí mo rántí, ẹ̀rù bà mí,
ìwárìrì sì mú mi lára.
7 Nítorí kí ní ènìyàn búburú fi wà ní
ayé, tí wọ́n gbó, àní tí wọ́n di alágbára ní ipa?
8 Irú-ọmọ wọn fi ìdí kalẹ̀ ní ojú
wọn pẹ̀lú wọn, àti ọmọ ọmọ wọn ní ojú wọn.
9 Ilé wọn wà láìní ewu àti ẹ̀rù, bẹ́ẹ̀
ni ọ̀pá ìbínú Ọlọ́run kò sí lára wọn.
10 Akọ màlúù wọn a máa gùn, kì í sì
tàsé; abo màlúù wọn a máa bí, kì í sì í ṣẹ́yun;
11 Wọn a máa rán àwọn ọmọ wọn
wẹ́wẹ́ jáde bí agbo ẹran, àwọn ọmọ wọn a sì máa jo kiri.
12 Wọ́n mú ohun ọ̀nà orin, ìlù àti
haapu, wọ́n sì ń yọ̀ sí ohùn fèrè.
13 Wọ́n n lo ọjọ́ wọn nínú ọrọ̀; wọn
sì lọ sí ipò òkú ní àlàáfíà.
14 Nítorí náà ni wọ́n ṣe wí fún Ọlọ́run pé, ‘Lọ kúrò lọ́dọ̀ wa!’
Nítorí pé wọn kò fẹ́ ìmọ̀ ipa ọ̀nà rẹ.
15 Kí ni Olódùmarè tí àwa ó fi máa sìn in?
Èrè kí ni a ó sì jẹ bí àwa ba gbàdúrà sí i?
16 Kíyèsi i, àlàáfíà wọn kò sí nípa
ọwọ́ wọn; ìmọ̀ ènìyàn búburú jìnnà sí mi réré.
17 “Ìgbà mélòó mélòó ní a ń pa fìtílà ènìyàn búburú kú?
Ìgbà mélòó mélòó ní ìparun wọn dé bá wọn,
tí Ọlọ́run sì í máa pín ìbìnújẹ́ nínú ìbínú rẹ̀?
18 Wọ́n dàbí àgékù koríko níwájú afẹ́fẹ́,
àti bí ìyàngbò, tí ẹ̀fúùfù ńlá fẹ́ lọ.
19 Ẹ̀yin wí pé, ‘Ọlọ́run to ìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ jọ fún àwọn ọmọ rẹ̀.’
Jẹ́ kí ó san án fún un, yóò sì mọ̀ ọ́n.
20 Ojú rẹ̀ yóò rí ìparun ara rẹ̀,
yóò sì máa mu nínú ríru ìbínú Olódùmarè.
21 Nítorí pé àlàáfíà kí ni ó ní nínú ilé rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀,
nígbà tí a bá ké iye oṣù rẹ̀ kúrò ní agbede-méjì?
22 “Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni le kọ Ọlọ́run ní ìmọ̀?
Òun ní í sá à ń ṣe ìdájọ́ ẹni ibi gíga.
23 Ẹnìkan a kú nínú pípé agbára rẹ̀,
ó wà nínú ìrora àti ìdákẹ́ pátápátá.
24 Ọpọ́n rẹ̀ kún fún omi ọmú,
egungun rẹ̀ sì tutù fún ọ̀rá.
25 Ẹlòmíràn a sì kú nínú kíkorò ọkàn rẹ̀,
tí kò sì fi inú dídùn jẹun.
26 Wọ́n o dùbúlẹ̀ bákan náà nínú erùpẹ̀,
kòkòrò yóò sì ṣùbò wọ́n.
27 “Kíyèsi i, èmi mọ̀ èrò inú yín àti
àrékérekè ọkàn yín láti ṣe ìlòdì sí mi.
28 Nítorí tí ẹ̀yin wí pé, ‘Níbo ní ilé ọmọ-aládé,
àti níbo ní àgọ́ àwọn ènìyàn búburú nì gbé wà?’
29 Ẹ̀yin kò béèrè lọ́wọ́ àwọn tí ń kọjá lọ ní ọ̀nà?
Ẹ̀yin kò mọ̀ ààmì wọn, pé
30 ènìyàn búburú ní a fi pamọ́ fún ọjọ́ ìparun.
A ó sì mú wọn jáde ní ọjọ́ ríru ìbínú.
31 Ta ni yóò tako ipa ọ̀nà rẹ̀ lójúkojú,
ta ni yóò sì san án padà fún un ní èyí tí ó ti ṣe?
32 Síbẹ̀ a ó sì sin ín ní ọ̀nà ipò òkú,
a ó sì máa ṣọ́ ibojì òkú.
33 Ògúlùtu àfonífojì yóò dùn mọ́ ọn.
Gbogbo ènìyàn yóò sì máa tọ̀ ọ́
lẹ́yìn, bí ènìyàn àìníye ti lọ síwájú rẹ̀.
34 “Èéha ti ṣe tí ẹ̀yin fi ń tù mí nínú lásán,
bí ò ṣe pé ní ìdáhùn yín, àrékérekè wa níbẹ̀!”
24 Lọ́jọ́ kejì wọ́n sì wọ Kesarea, Korneliu sì ti ń retí wọn, ó sì ti pe àwọn ìbátan àti àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ tímọ́tímọ́ jọ. 25 Ó sì ṣe bí Peteru ti ń wọlé, Korneliu pàdé rẹ̀, ó wólẹ̀ lẹ́sẹ̀ rẹ̀, ó sì foríbalẹ̀ fún un. 26 Ṣùgbọ́n Peteru gbé e dìde, ó ni, “Dìde ènìyàn ni èmi tìkára mi pẹ̀lú.”
27 Bí ó sì ti ń bá a sọ̀rọ̀, ó wọlé ó sì rí àwọn ènìyàn púpọ̀ tí wọ́n péjọ. 28 Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin mọ̀ bí ó ti jẹ́ èèwọ̀ fún ẹni tí ó jẹ́ Júù, láti bá ẹni tí ó jẹ́ ará ilẹ̀ mìíràn kẹ́gbẹ́, tàbí láti tọ̀ ọ́ wá; ṣùgbọ́n Ọlọ́run ti fihàn mi pé, ki èmi má ṣe pé ẹnikẹ́ni ni èèwọ̀ tàbí aláìmọ́. 29 Nítorí náà ni mo sì ṣe wá ní àìjiyàn, bí a ti ránṣẹ́ pè mi: ǹjẹ́ mo béèrè, nítorí kín ní ẹ̀yin ṣe ránṣẹ́ pè mi?”
30 Korneliu sì dáhùn pé, “Ní ìjẹrin, mo ń ṣe àdúrà wákàtí kẹsànán ọjọ́ ni ilé mi títí di idayìí, sì wò ó, ọkùnrin kan aláṣọ, àlà dúró níwájú mi. 31 Ó sì wí pé, ‘Korneliu, a gbọ́ àdúrà rẹ, ọrẹ-àánú rẹ̀ sì wà ni ìrántí níwájú Ọlọ́run. 32 Ǹjẹ́ ránṣẹ́ lọ sí Joppa, kí ó sì pe Simoni wá, ẹni ti àpèlé rẹ̀ ń jẹ́ Peteru; ó wọ̀ ní ilé Simoni aláwọ létí Òkun.’ 33 Nítorí náà ni mo sì ṣe ránṣẹ́ sì ọ lójúkan náà, ìwọ sì ṣeun tí ó fi wá. Gbogbo wa pé níwájú Ọlọ́run nísinsin yìí, láti gbọ́ ohun gbogbo, ti a pàṣẹ fún ọ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá.”
34 Peteru sì ya ẹnu rẹ, ó sì wí pé, “Nítòótọ́ mo wòye pé, Ọlọ́run kì í ṣe ojúsàájú ènìyàn. 35 Ṣùgbọ́n ni gbogbo orílẹ̀-èdè, ẹni tí ó bá bẹ̀rù rẹ̀, ti ó sì ń ṣiṣẹ́ òdodo, ẹni ìtẹ́wọ́gbà ni lọ́dọ̀ rẹ̀. 36 Ẹyin mọ ọrọ̀ tí Ọlọ́run rán sí àwọn ọmọ Israẹli láti kéde ìròyìn ayọ̀ àlàáfíà nípasẹ̀ Jesu Kristi, ẹni ti ṣe Olúwa ohun gbogbo 37 Ẹ̀yin náà mọ ọ̀rọ̀ náà tí a kéde rẹ̀ yíká gbogbo Judea, tí a bẹ̀rẹ̀ rẹ̀ láti Galili, lẹ́yìn bamitiisi ti Johanu wàásù rẹ̀. 38 Àní Jesu ti Nasareti, gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti da Ẹ̀mí Mímọ́ àti agbára le lórí; ẹni tí ó ń kiri ṣe oore, ó ń ṣe ìmúláradá gbogbo àwọn tí èṣù sì ń pọ́n lójú; nítorí Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀.
39 “Àwa sì ni ẹlẹ́rìí gbogbo ohun tí ó ṣe, ní ilẹ̀ àwọn Júù, àti ni Jerusalẹmu. Ẹni tí wọ́n pa nípa gbígbékọ́ sí orí igi. 40 Òun ni Ọlọ́run jí dìde ni ọjọ́ kẹta ó sì fi i hàn gbangba. 41 Kì í ṣe fún gbogbo ènìyàn ni o ri, bí kò ṣe fún àwa ti a jẹ́ ẹlẹ́rìí ti a ti ọwọ́ Ọlọ́run yàn tẹ̀lé, ti a bá a jẹ, ti a sì bá à mu lẹ́yìn ìgbà ti ó jíǹde kúrò nínú òkú. 42 Ó sì pàṣẹ fún wa láti wàásù fún àwọn ènìyàn, àti láti jẹ́rìí pé, òun ni a ti ọwọ́ Ọlọ́run yàn ṣe onídàájọ́ ààyè àti òkú. 43 Òun ni gbogbo àwọn wòlíì jẹ́rìí sì pé, ẹnikẹ́ni ti ó bá gbà á gbọ́ yóò rí ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ gbà nípa orúkọ rẹ̀.”
44 Bí Peteru sì ti ń sọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí lẹ́nu, Ẹ̀mí Mímọ́ bà lé gbogbo àwọn ti ó gbọ́ ọ̀rọ̀ náà. 45 Ẹnu sì yà àwọn onígbàgbọ́ ti a ti kọ nílà tí wọ́n bá Peteru wá, nítorí ti a tu ẹ̀bùn Ẹ̀mí Mímọ́ sórí àwọn aláìkọlà pẹ̀lú. 46 Nítorí wọ́n gbọ́, wọ́n ń fọ onírúurú èdè, wọn sì yin Ọlọ́run lógo.
Nígbà náà ni Peteru dáhùn wí pé, 47 “Ẹnikẹ́ni ha lè ṣòfin pe, kí a má bamitiisi àwọn wọ̀nyí tí wọ́n gba Ẹ̀mí Mímọ́ bí àwa?” 48 Ó sì pàṣẹ kí a bamitiisi wọn ni orúkọ Jesu Kristi. Nígbà náà ni wọ́n bẹ̀ ẹ́ kí ó dúró ni ọjọ́ mélòó kan.
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.