Old/New Testament
Ìdáhùn Jobu
17 “Ẹ̀mí mi bàjẹ́,
ọjọ́ mi ni a ti gé kúrú,
isà òkú dúró dè mí.
2 Nítòótọ́ àwọn ẹlẹ́yà wà lọ́dọ̀ mi,
ojú mi sì tẹ̀mọ́ ìmúnibínú wọn.
3 “Fi fún mi Olúwa, ìlérí tí ìwọ fẹ́;
ta ni yóò le ṣe ààbò fún mi?
4 Nítorí pé ìwọ ti sé wọ́n láyà kúrò nínú òye;
nítorí náà ìwọ kì yóò gbé wọn lékè.
5 Ẹni tí ó sọ ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn dídún fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ fún èrè,
òun ni ojú àwọn ọmọ rẹ̀ yóò mú òfo.
6 “Ọlọ́run ti sọ mi di ẹni òwe fún àwọn ènìyàn;
níwájú wọn ni mo dàbí ẹni ìtutọ́ sí ní ojú.
7 Ojú mí ṣú bàìbàì nítorí ìbìnújẹ́,
gbogbo ẹ̀yà ara mi sì dàbí òjìji.
8 Àwọn olódodo yóò yanu sí èyí,
ẹni aláìṣẹ̀ sì bínú sí àwọn àgàbàgebè.
9 Olódodo pẹ̀lú yóò di ọ̀nà rẹ̀ mú,
àti ọlọ́wọ́ mímọ́ yóò máa lera síwájú.
10 “Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti gbogbo yín,
ẹ yípadà, kí ẹ si tún padà nísinsin yìí;
èmi kò le rí ọlọ́gbọ́n kan nínú yín.
11 Ọjọ́ tí èmi ti kọjá, ìrò mi ti fà yá,
àní ìrò ọkàn mi.
12 Àwọn ènìyàn wọ̀nyí ń ṣọ́ òru di ọ̀sán;
wọ́n ní, ìmọ́lẹ̀ súnmọ́ ibi tí òkùnkùn dé.
13 Bí mo tilẹ̀ ní ìrètí, ipò òku ní ilé mi;
mo ti tẹ́ ibùsùn mi sínú òkùnkùn.
14 Èmi ti wí fún ìdíbàjẹ́ pé, ìwọ ni baba mi,
àti fún kòkòrò pé, ìwọ ni ìyá mi àti arábìnrin mi,
15 ìrètí mi ha dà nísinsin yìí?
Bí ó ṣe ti ìrètí mi ni, ta ni yóò rí i?
16 Yóò sọ̀kalẹ̀ lọ sínú ipò òkú,
nígbà tí a jùmọ̀ sinmi pọ̀ nínú erùpẹ̀ ilẹ̀?”
Ìdáhùn Bilidadi
18 Ìgbà náà ni Bilidadi, ará Ṣuhi, dáhùn, ó sì wí pé:
2 “Nígbà wo ni ẹ̀yin yóò tó fi ìdí ọ̀rọ̀ tì;
ẹ rò ó, nígbẹ̀yìn rẹ̀ ni àwa ó tó máa sọ.
3 Nítorí kí ni a ṣe ń kà wá sí bí ẹranko,
tí a sì ń kà wá si bí ẹni ẹ̀gàn ní ojú yín?
4 Ìwọ fa ara rẹ ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ nínú ìbínú rẹ̀;
kí a ha kọ ayé sílẹ̀ nítorí rẹ̀ bi?
Tàbí kí a sí àpáta kúrò ní ipò rẹ̀?
5 “Nítòótọ́ ìmọ́lẹ̀ ènìyàn búburú ni a ó pa kúrò,
Ọ̀wọ́-iná rẹ̀ kì yóò sì tan ìmọ́lẹ̀.
6 Ìmọ́lẹ̀ yóò di òkùnkùn nínú àgọ́ rẹ̀,
fìtílà ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ni a ó sì pa pẹ̀lú.
7 Ìrìn ẹsẹ̀ agbára rẹ̀ yóò di fífọ;
ète òun tìkára rẹ̀ ni yóò bí i ṣubú.
8 Nípa ẹ̀ṣẹ̀ òun tìkára rẹ̀ ó ti bọ́ sínú àwọ̀n,
ó sì rìn lórí okùn dídẹ.
9 Tàkúté ni yóò mú un ní gìgísẹ̀,
àwọn àwọ̀n tí a dẹ yóò sì ṣẹ́gun rẹ̀.
10 A dẹkùn sílẹ̀ fún un lórí ilẹ̀,
a sì wà ọ̀fìn fún un lójú ọ̀nà.
11 Ẹ̀rù ńlá yóò bà á ní ìhà gbogbo,
yóò sì lé e dé ẹsẹ̀ rẹ̀.
12 Àìlera rẹ̀ yóò di púpọ̀ fún ebi,
ìparun yóò dìde dúró sí i nígbà tí ó bá ṣubú.
13 Yóò jẹ ẹ̀yà ara rẹ̀;
ikú àkọ́bí ni yóò jẹ agbára rẹ̀ run.
14 A ó fà á tu kúrò nínú àgọ́ tí ó gbẹ́kẹ̀lé,
a ó sì mú un tọ ọba ẹ̀rù ńlá nì lọ.
15 Yóò sì máa jókòó nínú àgọ́ rẹ̀ èyí tí í ṣe tirẹ̀;
sulfuru ti o jóná ni a ó fún káàkiri ibùgbé rẹ̀.
16 Gbòǹgbò rẹ̀ yóò gbẹ níṣàlẹ̀,
a ó sì ké ẹ̀ka rẹ̀ kúrò lókè.
17 Ìrántí rẹ̀ yóò parun kúrò ni ayé,
kì yóò sí orúkọ rẹ̀ ní ìgboro ìlú.
18 A ó sì lé e láti inú ìmọ́lẹ̀ sí inú òkùnkùn,
a ó sì lé e kúrò ní ayé.
19 Kì yóò ní ọmọ tàbí ọmọ ọmọ nínú àwọn ènìyàn rẹ̀,
Bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò kù nínú agbo ilé rẹ̀.
20 Ẹnu yóò ya àwọn ìran ti ìwọ̀-oòrùn sí ìgbà ọjọ́ rẹ̀,
gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rù ìwárìrì ti í bá àwọn ìran ti ìlà-oòrùn.
21 Nítòótọ́ irú bẹ́ẹ̀ ni ibùgbé àwọn
ènìyàn búburú Èyí sì ni ipò ẹni tí kò mọ̀ Ọlọ́run.”
Ìdáhùn Jobu fún Bilidadi
19 Ìgbà náà ni Jobu dáhùn, ó sì wí pé:
2 “Yóò ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin ó fi máa fi ìyà jẹ mí,
tí ẹ̀yin ó fi máa fi ọ̀rọ̀ yìí?
3 Ìgbà mẹ́wàá ní yin yọ mi lénu ẹ̀yin ti ń gàn mí;
ojú kò tì yín tí ẹ fi jẹ mí ní yà.
4 Kí a sì wí bẹ́ẹ̀ pé, mo ṣìnà nítòótọ́,
ìṣìnà mi wà lára èmi tìkára mi.
5 Bí ó tilẹ̀ ṣe pé ẹ̀yin ó ṣògo si mi lórí nítòótọ́,
tí ẹ ó sì máa fi ẹ̀gàn mi gún mí lójú,
6 Kí ẹ mọ̀ nísinsin yìí pé, Ọlọ́run ni ó bì mí ṣubú,
ó sì nà àwọ̀n rẹ̀ yí mi ká.
7 “Kíyèsi, èmi ń kígbe pe, ‘Ọwọ́ alágbára!’ Ṣùgbọ́n a kò gbọ́ ti èmi;
mo kígbe fún ìrànlọ́wọ́, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ìdájọ́.
8 Ó ṣọgbà dí ọ̀nà mi tí èmi kò le è kọjá,
Ó sì mú òkùnkùn ṣú sí ipa ọ̀nà mi.
9 Ó ti bọ́ ògo mi,
ó sì ṣí adé kúrò ní orí mi.
10 Ó ti bà mí jẹ́ ní ìhà gbogbo,
ẹ̀mí sì pin; ìrètí mi ni a ó sì fàtu bí igi.
11 Ó sì tiná bọ ìbínú rẹ̀ sí mi,
ó sì kà mí sí bí ọ̀kan nínú àwọn ọ̀tá rẹ̀.
12 Ẹgbẹ́ ogun rẹ̀ sì dàpọ̀ sí mi,
wọ́n sì mọ odi yí mi ká,
wọ́n sì yí àgọ́ mi ká.
13 “Ó mú àwọn arákùnrin mi jìnà sí mi réré,
àti àwọn ojúlùmọ̀ mi di àjèjì sí mi pátápátá.
14 Àwọn alájọbí mi fàsẹ́yìn,
àwọn ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́ mi sì di onígbàgbé mi.
15 Àwọn ará inú ilé mi àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin mi kà mí sí àjèjì;
èmi jásí àjèjì ènìyàn ní ojú wọn.
16 Mo pe ìránṣẹ́ mi, òun kò sì dá mi lóhùn;
mo fi ẹnu mi bẹ̀ ẹ́.
17 Ẹ̀mí mi ṣú àyà mi, àti òórùn mi
ṣú àwọn ọmọ inú ìyá mi.
18 Àní àwọn ọmọdékùnrin fi mí ṣẹ̀sín:
Mo dìde, wọ́n sì sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí mi.
19 Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ kòríkòsùn mi kórìíra mi,
àwọn olùfẹ́ mi sì kẹ̀yìndà mí.
20 Egungun mi lẹ̀ mọ́ ara mi àti mọ́ ẹran-ara mi,
mo sì yọ́ pẹ̀lú awọ eyín mi.
21 “Ẹ ṣàánú fún mi, ẹ ṣàánú fún mi,
ẹ̀yin ọ̀rẹ́ mi, nítorí ọwọ́ Ọlọ́run ti bà mí.
22 Nítorí kí ni ẹ̀yin ṣe lépa mi bí
Ọlọ́run, tí ẹran-ara mi kò tẹ́ yín lọ́rùn?
23 “Háà! Ìbá ṣe pé a le kọ̀wé ọ̀rọ̀ mi
nísinsin yìí, ìbá ṣe pé a le kọ ọ sínú ìwé!
24 Kí a fi kálámù irin àti ti òjé kọ
wọ́n sínú àpáta fún láéláé.
25 Nítorí èmi mọ̀ pé olùdáǹdè mi ń bẹ láààyè
àti pe òun ni yóò dìde dúró lórí ilẹ̀ ní ìkẹyìn;
26 Àti lẹ́yìn ìgbà tí a pa àwọ̀ ara
mi run, síbẹ̀ láìsí ẹran-ara mi ni èmi ó rí Ọlọ́run,
27 Ẹni tí èmi ó rí fún ara mi,
tí ojú mi ó sì wo, kì sì í ṣe ti ẹlòmíràn;
ọkàn mi sì dákú ní inú mi.
28 “Bí ẹ̀yin bá wí pé, ‘àwa ó ti lépa rẹ̀ tó!
Àti pé, gbogbo ọ̀rọ̀ náà ni a sá à rí ní ọwọ́ rẹ̀,’
29 Kí ẹ̀yin kí ó bẹ̀rù;
nítorí ìbínú ní í mú ìjìyà wá nípa idà,
Kí ẹ̀yin kí ó lè mọ̀ pé ìdájọ́ kan ń bẹ.”
Àwọn ìpè Korneliu fún Peteru
10 (A)Ọkùnrin kan sì wà ni Kesarea ti a ń pè ní Korneliu, balógun ọ̀rún ti ẹgbẹ́ ọmọ-ogun tí a ń pè ni Itali. 2 Olùfọkànsìn, àti ẹni ti ó bẹ̀rù Ọlọ́run tilétilé rẹ̀ gbogbo, ẹni tí ó ń tọrẹ àánú púpọ̀ fún àwọn ènìyàn, tí ó sì ń gbàdúrà sọ́dọ̀ Ọlọ́run nígbà gbogbo. 3 Níwọ́n wákàtí kẹsànán ọjọ́, ó rí nínú ìran kedere angẹli Ọlọ́run kan wọlé tọ̀ ọ́ wá, ó sì wí fún un pé, “Korneliu!”
4 Nígbà tí ó sì tẹjúmọ́ ọn, ti ẹ̀rù sì bà á, ó ní, “Kín ni, Olúwa?”
Ó sì wí fún un pé, “Àdúrà rẹ àti ọrẹ-àánú, tìrẹ gòkè lọ síwájú Ọlọ́run fún ìrántí. 5 Sì rán ènìyàn nísinsin yìí lọ sí Joppa, kí wọn sì pe Simoni wá, ẹni ti àpèlé rẹ̀ ń jẹ́ Peteru. 6 Ó wọ̀ sí ilé Simoni aláwọ, tí ilé rẹ̀ wà létí Òkun; òun ni yóò sọ fún ọ bí ìwọ ó ti ṣe.”
7 Nígbà tí angẹli náà tí ó bá Korneliu sọ̀rọ̀ sì fi i sílẹ̀ lọ ó pe méjì nínú àwọn ìránṣẹ́ ilé rẹ̀, àti ọmọ-ogun olùfọkànsìn kan, nínú àwọn ti ó máa ń dúró tì í nígbà gbogbo. 8 Nígbà tí ó sì tí ṣàlàyé ohun gbogbo fún wọn, ó rán wọn lọ sí Joppa.
Ìran Peteru
9 Ni ọjọ́ kejì bí wọ́n ti ń lọ lọ́nà àjò wọn, tí wọ́n sì súnmọ́ ilé náà, Peteru gun òkè ilé lọ láti gbàdúrà ni ìwọ̀n wákàtí kẹfà ọjọ́: 10 Ebi sì pa á gidigidi, ó sì ń fẹ́ láti jẹun: ó bọ́ sí ojúran. 11 Ó sì rí ọ̀run ṣí, ohun èlò kan si sọ̀kalẹ̀ bí gọgọwú ńlá, tí a ti igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin, sọ̀kalẹ̀ sí ilẹ̀: 12 Nínú rẹ̀ ni onírúurú ẹranko ẹlẹ́ṣẹ̀ mẹ́rin wà, àti ohun tí ń rákò ni ayé àti ẹyẹ ojú ọ̀run. 13 Ohùn kan si fọ̀ sí i pe, “Dìde, Peteru; máa pa kí o sì máa jẹ.”
14 Ṣùgbọ́n Peteru dáhùn pé, “rara, Olúwa; nítorí èmi kò jẹ ohun èèwọ̀ àti aláìmọ́ kan rí.”
15 Ohùn kan sì tún fọ̀ sí i lẹ́ẹ̀méjì pé, “Ohun tí Ọlọ́run bá ti wẹ̀mọ́, ìwọ má ṣe pè é ní èèwọ̀ mọ́.”
16 Èyí sì ṣe lẹ́ẹ̀mẹ́ta; lójúkan náà a sì gbé ohun èlò náà padà lọ sókè ọ̀run.
Korneliu ránṣẹ́ sí Peteru
17 Bí Peteru sì ti ń dààmú nínú ara rẹ̀ bí òun bá ti mọ̀ ìran tí òun ri yìí sí, si wò ó, àwọn ọkùnrin tí a rán wá láti ọ̀dọ̀ Korneliu dé. Wọ́n ń béèrè ilé Simoni, wọ́n dúró ní ẹnu-ọ̀nà. 18 Wọn nahùn béèrè bí Simoni tí a ń pè ní Peteru, wọ̀ níbẹ̀.
19 Bí Peteru sì ti ń ronú ìran náà, Ẹ̀mí wí fún un pé, “Wò ó, àwọn ọkùnrin mẹ́ta ń wá ọ. 20 Ǹjẹ́ dìde, sọ̀kalẹ̀ kí ó sì bá wọn lọ, má ṣe kó ara ró láti bá wọn lọ: nítorí èmi ni ó rán wọn.”
21 Nígbà náà ni Peteru sọ̀kalẹ̀ tọ àwọn ọkùnrin náà tí a rán, ó sì wí pé, “Wò ó, èmi ni ẹni tí ẹ̀yin ń wá: kín ni ìdí rẹ̀ ti ẹ fi wá?”
22 Wọ́n sì wí pé, “Korneliu balógun ọ̀rún, ọkùnrin olóòtítọ́, àti ẹni ti ó bẹ̀rù Ọlọ́run, tí ó sì ní orúkọ rere lọ́dọ̀ gbogbo orílẹ̀-èdè àwọn Júù, òun ni a ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run kọ́ nípasẹ̀ angẹli mímọ́, láti ránṣẹ́ pè ọ́ wá sí ilé rẹ̀ àti láti gbọ́ ọ̀rọ̀ lẹ́nu rẹ.” 23 Nígbà náà ni Peteru pè wọ́n wọlé, ó gbà wọ́n lálejò.
Peteru ní ilé Korneliu
Ní ọjọ́ kejì, ó sì dìde, ó bá wọn lọ, díẹ̀ nínú àwọn ti o ti gbàgbọ́ ní Joppa sì bá a lọ pẹ̀lú.
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.