Print Page Options
Previous Prev Day Next DayNext

Old/New Testament

Each day includes a passage from both the Old Testament and New Testament.
Duration: 365 days
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Version
Jobu 11-13

Sofari fi ẹ̀sùn irọ́ pípa àti àìṣòótọ́ kan Jobu

11 Ìgbà náà ni Sofari, ará Naama, dáhùn, ó sì wí pé:

“A ha lè ṣe kí a máa dáhùn sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọ̀rọ̀?
    A ha lè fi gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí da ènìyàn láre?
Ṣé àmọ̀tán rẹ le mú ènìyàn pa ẹnu wọn mọ́ bí?
    Ṣé ẹnikẹ́ni kò ní bá ọ wí bí ìwọ bá yọ ṣùtì sí ni?
Ìwọ sá à ti wí fún Ọlọ́run pé,
    ‘ìṣe mi jẹ́ aláìléérí, èmi sì mọ́ ní ojú rẹ.’
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run ìbá jẹ́ sọ̀rọ̀,
    kí ó sì ya ẹnu rẹ̀ sí ọ;
Kí ó sì fi àṣírí ọgbọ́n hàn ọ́ pé, ó pọ̀ ju òye ènìyàn lọ;
    Nítorí náà, mọ̀ pé Ọlọ́run ti
    gbàgbé àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kan.

“Ìwọ ha le ṣe àwárí ohun ìjìnlẹ̀ Ọlọ́run bí?
    Ìwọ ha le ṣe àwárí ibi tí Olódùmarè dé bi?
Ó ga ju àwọn ọ̀run lọ; kí ni ìwọ le è ṣe?
    Ó jì ju jíjìn isà òkú lọ; kí ni ìwọ le mọ̀?
Ìwọ̀n rẹ̀ gùn ju ayé lọ,
    ó sì ní ibú ju Òkun lọ.

10 “Bí òun bá rékọjá, tí ó sì sé ọnà,
    tàbí tí ó sì mú ni wá sí ìdájọ́, ǹjẹ́, ta ni ó lè dí i lọ́wọ́?
11 Òun sá à mọ ẹlẹ́tàn ènìyàn;
    àti pé ṣé bí òun bá rí ohun búburú, ṣé òun kì i fi iyè sí i?
12 Ṣùgbọ́n òmùgọ̀ ènìyàn ki yóò di ọlọ́gbọ́n,
    bi ko ti rọrùn fún ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó láti bí ènìyàn.

13 “Bí ìwọ bá fi ọkàn rẹ fún un,
    tí ìwọ sì na ọwọ́ rẹ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀,
14 Bí ìwọ bá gbé ẹ̀ṣẹ̀ tí ń bẹ ní ọwọ́ rẹ jù sọnù,
    tí ìwọ kò sì jẹ́ kí aburú gbé nínú àgọ́ rẹ.
15 Nígbà náà ni ìwọ ó gbé ojú rẹ sókè láìní àbàwọ́n,
    àní ìwọ yóò dúró ṣinṣin, ìwọ kì yóò sì bẹ̀rù,
16 Nítorí pé ìwọ ó gbàgbé ìṣòro rẹ,
    ìwọ ó sì rántí rẹ̀ bí omi tí ó ti sàn kọjá lọ.
17 Ọjọ́ ayé rẹ yóò sì mọ́lẹ̀ ju ọ̀sán gangan lọ,
    bí òkùnkùn tilẹ̀ bò ọ́ mọ́lẹ̀ nísinsin yìí, ìwọ ó dàbí òwúrọ̀.
18 Ìwọ ó sì wà láìléwu, nítorí pé ìrètí wà;
    àní ìwọ ó rin ilé rẹ wò, ìwọ ó sì sinmi ní àlàáfíà.
19 Ìwọ ó sì dùbúlẹ̀ pẹ̀lú, kì yóò sì sí ẹni tí yóò dẹ́rùbà ọ́,
    àní ènìyàn yóò máa wá ojúrere rẹ.
20 Ṣùgbọ́n ojú ìkà ènìyàn yóò mófo;
    gbogbo ọ̀nà àbáyọ ni yóò nù wọ́n,
    ìrètí wọn a sì dàbí ẹni tí ó jọ̀wọ́ ẹ̀mí rẹ̀ lọ́wọ́.”

Ìdáhùn Jobu

12 Jobu sì dáhùn, ó sì wí pé:

“Kò sí àní àní níbẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ni àwọn ènìyàn náà,
    ọgbọ́n yóò sì kú pẹ̀lú yín!
Ṣùgbọ́n èmi ní ìyè nínú gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin:
    èmi kò kéré sí i yín:
    àní, ta ni kò mọ gbogbo nǹkan wọ̀nyí?

“Èmi dàbí ẹni tí a ń fi ṣe ẹlẹ́yà lọ́dọ̀ aládùúgbò rẹ̀,
    tí ó ké pe Ọlọ́run, tí ó sì dá a lóhùn:
    à ń fi olóòtítọ́ ẹni ìdúró ṣinṣin rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà.
Ó rọrùn fún ènìyàn láti fi ìbànújẹ́ ẹlòmíràn ṣe ẹlẹ́yà,
    gẹ́gẹ́ bí ìpín àwọn ẹni tí ẹsẹ̀ wọn ṣetán láti yọ̀.
Àgọ́ àwọn ìgárá ọlọ́ṣà wá láìní ìbẹ̀rù;
    àwọn tí ó sì ń mú Ọlọ́run bínú wà láìléwu,
    àwọn ẹni tí ó sì gbá òrìṣà mú ní ọwọ́ wọn.

“Ṣùgbọ́n nísinsin yìí bí àwọn ẹranko léèrè, wọn o kọ́ ọ ní ẹ̀kọ́,
    àti ẹyẹ ojú ọ̀run, wọn ó sì sọ fún ọ.
Tàbí ba ilẹ̀ ayé sọ̀rọ̀, yóò sì kọ́ ọ,
    àwọn ẹja inú Òkun yóò sì sọ fún ọ.
Ta ni kò mọ̀ nínú gbogbo nǹkan
    wọ̀nyí pé, ọwọ́ Olúwa ni ó ṣe nǹkan yìí?
10 Ní ọwọ́ ẹni tí ẹ̀mí ohun alààyè gbogbo gbé wà,
    Àti ẹ̀mí gbogbo aráyé.
11 Etí kì í dán ọ̀rọ̀ wò bí
    tàbí adùn ẹnu kì í sì í tọ́ oúnjẹ rẹ̀ wò bí?
12 Àwọn arúgbó ni ọgbọ́n wà fún,
    àti nínú gígùn ọjọ́ ni òye.

13 “Ti Ọlọ́run ni ọgbọ́n àti agbára:
    Òun ló ni ìmọ̀ àti òye.
14 Kíyèsi i, ó bì wó, a kò sì lè gbe ró mọ́;
    Ó sé ènìyàn mọ́, kò sì sí ìtúsílẹ̀ kan.
15 Kíyèsi i, ó dá àwọn omi dúró, wọ́n sì gbẹ;
    Ó sì rán wọn jáde, wọ́n sì ṣẹ̀ bo ilẹ̀ ayé yípo.
16 Tìrẹ ni agbára àti ìṣẹ́gun;
    Ẹni tí ń ṣìnà àti ẹni tí ń mú ni ṣìnà, tirẹ̀ ni wọ́n ń ṣe.
17 Ó mú àwọn ìgbìmọ̀ lọ ní ìhòhò,
    A sì sọ àwọn onídàájọ́ di òmùgọ̀.
18 Ó tú ìdè ọba,
    Ó sì fi àmùrè gbà wọ́n ní ọ̀já.
19 Ó mú àwọn àlùfáà lọ ní ìhòhò,
    Ó sì tẹ orí àwọn alágbára ba.
20 Ó mú ọ̀rọ̀ ẹnu ẹni ìgbẹ́kẹ̀lé kúrò,
    Ó sì ra àwọn àgbàgbà ní iyè.
21 Ó bu ẹ̀gàn lu àwọn ọmọ ọlọ́lá,
    Ó sì tú àmùrè àwọn alágbára.
22 Ó hú ìdí ohun ìjìnlẹ̀ jáde láti inú òkùnkùn wá,
    Ó sì mú òjìji ikú wá sínú ìmọ́lẹ̀.
23 Òun a mú orílẹ̀-èdè bí sí i, a sì run wọ́n;
    Òun a sọ orílẹ̀-èdè di ńlá, a sì tún ṣẹ̀ wọn kù.
24 Òun a gba òye àwọn olórí àwọn ènìyàn aráyé,
    A sì máa mú wọn rin kiri nínú ijù níbi tí ọ̀nà kò sí.
25 Wọn a máa fi ọwọ́ ta ilẹ̀ nínú òkùnkùn níbi tí kò sí ìmọ́lẹ̀,
    Òun a sì máa mú ìrìn ìsìn wọn bí ọ̀mùtí.

Jobu gbẹ́kẹ̀lé Ọlọ́run

13 “Wò ó, ojú mi ti rí gbogbo èyí rí,
    etí mí sì gbọ́, ó sì ti yé mi.
Ohun tí ẹ̀yin mọ̀, èmi mọ̀ pẹ̀lú,
    èmi kò kéré sí i yin.
Nítòótọ́ èmi ó bá Olódùmarè
    sọ̀rọ̀, èmi sì ń fẹ́ bá Ọlọ́run sọ àsọyé.
Ẹ̀yin fi irọ́ bá mi sọ̀rọ̀,
    oníṣègùn lásán ni gbogbo yín.
Háà! ẹ̀yin kì bá kúkú dákẹ́!
    Èyí ni kì bá sì ṣe ọgbọ́n yín.
Ẹ gbọ́ àwíyé mi nísinsin yìí;
    ẹ sì fetísílẹ̀ sí àròyé ẹnu mi.
Ẹ̀yin fẹ́ sọ ìsọkúsọ fún Ọlọ́run?
    Ki ẹ sì fi ẹ̀tàn sọ̀rọ̀ gbè é?
Ẹ̀yin fẹ́ ṣe ojúsàájú rẹ̀?
    Ẹ̀yin fẹ́ gbèjà fún Ọlọ́run?
Ó ha dára to tí yóò hú àṣírí yín síta,
    Tàbí kí ẹ̀yin tàn án bí ẹnìkan ti í tan ẹnìkejì?
10 Yóò máa bá yín wí nítòótọ́,
    bí ẹ̀yin bá ṣe ojúsàájú ènìyàn níkọ̀kọ̀.
11 Ìwà ọlá rẹ̀ kì yóò bà yín lẹ́rù bí?
    Ìpayà rẹ̀ kì yóò pá yín láyà?
12 Àwọn òwe yín dàbí eérú;
    Bẹ́ẹ̀ ni àwọn odi ìlú yin dàbí amọ̀.

13 “Ẹ pa ẹnu yín mọ́ kúrò lára mi, kí èmi kí ó lè sọ̀rọ̀,
    ki ohun tí ń bọ̀ wá í bá mi, le è máa bọ̀.
14 Ǹjẹ́ nítorí kí ni èmi ṣe ń fi eyín mi bu ẹran-ara mi jẹ,
    Tí mo sì gbé ẹ̀mí mi lé ara mi lọ́wọ́?
15 Bí ó tilẹ̀ pa mí, síbẹ̀ èmi ó máa gbẹ́kẹ̀lé e;
    Ṣùgbọ́n èmi ó máa tẹnumọ́ ọ̀nà mi níwájú rẹ̀.
16 Èyí ni yóò sì ṣe ìgbàlà mi,
    Àgàbàgebè kì yóò wá síwájú rẹ̀.
17 Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹnu mi ní ìfarabalẹ̀,
    jẹ́ kí ọ̀rọ̀ mí dún ni etí yín.
18 Wò ó nísinsin yìí, èmi ti mura ọ̀ràn mi sílẹ̀;
    èmi mọ̀ pé a ó dá mi láre.
19 Ta ni òun ti yóò bá mi ṣàròyé?
    Ǹjẹ́ nísinsin yìí, èmi fẹ́ pa ẹnu mi mọ́,
    èmi ó sì jọ̀wọ́ ẹ̀mí mi lọ́wọ́.

20 “Ṣùgbọ́n, má ṣe ṣe ohun méjì yìí sí mi,
    Nígbà náà ni èmi kì yóò sì fi ara mi pamọ́ kúrò fún ọ:
21 Fa ọwọ́ rẹ sẹ́yìn kúrò lára mi,
    má sì jẹ́ kí ẹ̀rù rẹ kí ó pá mi láyà.
22 Nígbà náà ni kí ìwọ kí ó pè, èmi o sì dáhùn;
    Ta ni jẹ́ kí ń máa sọ̀rọ̀, ki ìwọ kí ó sì dá mi lóhùn.
23 Mélòó ní àìṣedéédéé àti ẹ̀ṣẹ̀ mi?
    Mú mi mọ̀ ìrékọjá àti ẹ̀ṣẹ̀ mi.
24 Nítorí kí ni ìwọ ṣe pa ojú rẹ mọ́,
    tí o sì yàn mí ní ọ̀tá rẹ?
25 Ìwọ ó fa ewé ti afẹ́fẹ́ ń fẹ́ síhìn-ín sọ́hùn-ún ya bi?
    Ìwọ a sì máa lépa ìyàngbò?
26 Nítorí pé ìwọ kọ̀wé ohun kíkorò sí mi,
    o sì mú mi jogún àìṣedéédéé èwe mi.
27 Ìwọ kàn àbà mọ́ mi lẹ́sẹ̀ pẹ̀lú,
    ìwọ sì ń wò ipa ọ̀nà ìrìn mi ní àwòfín;
    nípa fífi ìlà yí gígísẹ̀ mi ká.

28 “Bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn ń ṣègbé bí ohun ìdíbàjẹ́,
    Bi aṣọ tí kòkòrò jẹ.

Ìṣe àwọn Aposteli 9:1-21

Ìyípadà Saulu

(A)Ṣùgbọ́n síbẹ̀, Saulu sí ń tẹ̀síwájú nínú mímí-èémí ìhalẹ̀-mọ́ni àti ìpani sí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Olúwa. Ó tọ olórí àlùfáà lọ, ó béèrè ìwé lọ́wọ́ rẹ̀ sí Sinagọgu tí ń bẹ ní ìlú Damasku pé, bí òun bá rí ẹnikẹ́ni tí ń bẹ ni Ọ̀nà yìí, ìbá à ṣe ọkùnrin, tàbí obìnrin, kí òun lè mú wọn ní dídè wá sí Jerusalẹmu. Ó sì ṣe, bí ó ti ń lọ, ó sì súnmọ́ Damasku; lójijì, ìmọ́lẹ̀ láti ọ̀run wá mọ́lẹ̀ yí i ká. Ó sì ṣubú lulẹ̀, ó gbọ́ ohùn tí ó ń fọ̀ sí i pé, “Saulu, Saulu, èéṣe ti ìwọ fi ń ṣe inúnibíni sí mi?”

Ó sì wí pé, “Ìwọ ta ni, Olúwa?”

Olúwa sì wí pé, “Èmi ni Jesu, ẹni ti ìwọ ń ṣe inúnibíni sí; (ohùn ìrora ni fún ọ láti tàpá sí ẹ̀gún). Ó sì ń wárìrì, ẹnu sì yà á, ó ni Olúwa, kín ní ìwọ ń fẹ́ kí èmi ṣe? Olúwa sì wí fún pé, Dìde, kí o sì lọ sí ìlú náà, a ó sì sọ fún ọ nípa ohun tí ìwọ yóò ṣe.”

Àwọn ọkùnrin tí wọ́n sì ń bá Saulu lọ àjò dúró, wọn kò sì le sọ ohun kan, wọn gbọ́ ohùn náà ṣùgbọ́n wọn kò rí ẹnìkan. Saulu sì dìde ní ilẹ̀; nígbà tí ojú rẹ̀ sì lá kò rí ohunkóhun; ṣùgbọ́n wọ́n fà á lọ́wọ́ wọ́n sì mú un wá sí Damasku. Ó sì gbé ọjọ́ mẹ́ta ni àìríran kò sì jẹ, bẹ́ẹ̀ ni kò sì mu.

10 Ọmọ-ẹ̀yìn kan sì wà ní Damasku, tí a ń pè ni Anania! Olúwa sì wí fún un lójúran pé, “Anania!”

Ó sì wí pé, “Wò ó, èmi nìyí, Olúwa.”

11 Olúwa sì wí fún un pé, “Dìde kí ó sì lọ sí ilé Judasi ní Òpópónà Tààrà, kí ó sì béèrè ẹni tí a ń pè ni Saulu, ara Tarsu, sá wò ó, ó ń gbàdúrà. 12 Òun sì tí ri ọkùnrin kan lójúran ti a ń pè ni Anania, ó wọlé, ó sì fi ọwọ́ lé e, kí ó lè ríran.”

13 Anania sì dáhùn wí pé, “Olúwa mo tí gbúròó ọkùnrin yìí lọ́dọ̀ ọ̀pọ̀ ènìyàn, gbogbo búburú ti ó ṣe sí àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ ni Jerusalẹmu. 14 Ó sì gba àṣẹ láti ọ̀dọ̀ àwọn olórí àlùfáà wá sí ìhín yìí, láti de gbogbo àwọn ti ń pe orúkọ rẹ.”

15 Ṣùgbọ́n Olúwa wí fún un pé, “Máa lọ; nítorí ohun èlò ààyò ni òun jẹ́ fún mi, láti gbé orúkọ mi lọ sí iwájú àwọn aláìkọlà, àti àwọn ọba, àti àwọn ọmọ Israẹli. 16 Nítorí èmi o fi gbogbo ìyà ti kò le ṣàìjẹ nítorí orúkọ mi hàn án.”

17 Anania sì lọ, ó sì wọ ilé náà, nígbà tí ó fi ọwọ́ rẹ̀ lé Saulu, ó sì wí pé, “Arákùnrin Saulu, Olúwa ni ó rán mi, Jesu tí ó fi ara hàn ọ lọ́nà tí ìwọ bá wá, kí ìwọ ba à lè ríran, kí ó sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́.” 18 Lójúkan náà nǹkan kan ti ó dàbí ìpẹ́ sì bọ kúrò lójú rẹ̀, ó sì ríran; ó sì dìde, a sì bamitiisi rẹ̀. 19 Nígbà tí ó sì jẹun, ara rẹ̀ mókun.

Saulu ní Damasku àti Jerusalẹmu

Saulu sì wá pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn ní Damasku ní ọjọ́ púpọ̀ 20 Lójúkan náà ó sì ń wàásù Kristi nínú àwọn Sinagọgu pé, Jesu ni Ọmọ Ọlọ́run. 21 Ẹnu sì yà gbogbo àwọn ti ó ń gbọ́, wọn sì wí pé, “Èyí ha kọ ẹni ti ó ti fóòro àwọn ti ń pe orúkọ yìí ni Jerusalẹmu? Nítorí èyí náà ni ó sa ṣe wá sí ìhín yìí, láti mú wọn ní dìde lọ sọ́dọ̀ àwọn olórí àlùfáà.”

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)

Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.