Print Page Options
Previous Prev Day Next DayNext

Old/New Testament

Each day includes a passage from both the Old Testament and New Testament.
Duration: 365 days
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Version
Jobu 3-4

Jobu ráhùn sí Ọlọ́run

Ẹ̀yìn èyí ní Jobu yanu, ó sì fi ọjọ́ ìbí rẹ̀ ré Jobu sọ, ó sì wí pé:

(A)“Kí ọjọ́ tí a bí mi kí ó di ìgbàgbé,
    àti òru ni, nínú èyí tí a wí pé, ‘A lóyún ọmọkùnrin kan!’
Kí ọjọ́ náà kí ó já si òkùnkùn,
    kí Ọlọ́run kí ó má ṣe kà á sí láti ọ̀run wá;
    bẹ́ẹ̀ ni kí ìmọ́lẹ̀ kí ó má ṣe mọ́ sí i.
Kí òkùnkùn àti òjìji ikú fi ṣe ti ara wọn;
    kí àwọsánmọ̀ kí ó bà lé e;
    kí ìṣúdudu ọjọ́ kí ó pa láyà.
Kí òkùnkùn kí ó ṣú bo òru náà biribiri,
    kí ó má ṣe yọ pẹ̀lú ọjọ́ ọdún náà:
    kí a má ṣe kà a mọ́ iye ọjọ́ oṣù.
Kí òru náà kí ó yàgàn;
    kí ohun ayọ̀ kan kí ó má ṣe wọ inú rẹ̀ lọ.
Kí àwọn tí í fi ọjọ́ gégùn ún kí o fi gégùn ún,
    tí wọ́n mura tán láti ru Lefitani sókè.
Kí ìràwọ̀ òwúrọ̀ ọjọ́ rẹ̀ kí ó ṣókùnkùn;
    kí ó má wá ìmọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n kí ó máa mọ́ sí i,
    bẹ́ẹ̀ ni kí ó má ṣe rí àfẹ̀mọ́júmọ́
10 Nítorí tí kò sé ìlẹ̀kùn inú ìyá mi,
    láti pa ìbànújẹ́ rẹ́ ní ojú mi.

11 “Èéṣe tí èmi kò fi kú láti inú wá,
    tàbí tí èmi kò kú ní ìgbà tí mo ti inú jáde wá?
12 Èéṣe tí orúnkún wá pàdé mi,
    tàbí ọmú tí èmi yóò mu?
13 Ǹjẹ́ nísinsin yìí èmi ìbá ti dùbúlẹ̀ jẹ́ẹ́;
    èmi ìbá ti sùn, èmi ìbá ti sinmi
14 pẹ̀lú àwọn ọba àti ìgbìmọ̀ ayé
    tí wọ́n mọ ilé fún ara wọn wá dùbúlẹ̀ nínú ìsọdahoro.
15 Tàbí pẹ̀lú àwọn ọmọ-aládé
    tí ó ní wúrà, tí wọ́n sì fi fàdákà kun ilé wọn
16 Tàbí bí ọlẹ̀ tí a sin, èmi kì bá ti sí:
    bí ọmọ ìṣunú tí kò rí ìmọ́lẹ̀?
17 Níbẹ̀ ni ẹni búburú ṣíwọ́ ìyọnilẹ́nu,
    níbẹ̀ ni ẹni àárẹ̀ wà nínú ìsinmi.
18 Níbẹ̀ ni àwọn ìgbèkùn sinmi pọ̀,
    wọn kò gbóhùn amúnisìn mọ́.
19 Àti èwe àti àgbà wà níbẹ̀,
    ẹrú sì di òmìnira kúrò lọ́wọ́ olówó rẹ̀.

Jobu kígbe nínú ìrora rẹ̀

20 “Nítorí kí ni a ṣe fi ìmọ́lẹ̀ fún òtòṣì,
    àti ìyè fún ọlọ́kàn kíkorò,
21 tí wọ́n dúró de ikú, ṣùgbọ́n òun kò wá,
    tí wọ́n wá a jù ìṣúra tí a bò mọ́lẹ̀ pamọ́ lọ.
22 Ẹni tí ó yọ̀ gidigidi,
    tí inú wọ́n sì dùn nígbà tí wọ́n wá ibojì òkú rí?
23 Kí ni a fi ìmọ́lẹ̀ fún ẹni
    tí ọ̀nà rẹ̀ fi ara pamọ́ fún,
    tí Ọlọ́run sì ṣọgbà dí mọ́ ká?
24 Nítorí pé èémí-ẹ̀dùn wà ṣáájú oúnjẹ mi;
    ìkérora mi sì tú jáde bí omi.
25 Nítorí pé ohun náà tí mo bẹ̀rù gidigidi ni ó dé bá mi yìí,
    àti ohun tí mo fòyà rẹ̀ bá mi ó sì ṣubú lù mí.
26 Èmi wà láìní àlàáfíà, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò ní ìsinmi;
    bẹ́ẹ̀ ni èmi kò ni ìfàyàbalẹ̀, bí kò ṣe ìdààmú.”

Ọ̀rọ̀ Elifasi: Ọlọ́run kì í fi ìyà jẹ olódodo

Ìgbà náà ni Elifasi, ará Temani dáhùn wí pé:

“Bí àwa bá fi ẹnu lé e, láti bá ọ sọ̀rọ̀, ìwọ o ha banújẹ́?
    Ṣùgbọ́n ta ni ó lè pa ọ̀rọ̀ mọ́ ẹnu láìsọ?
Kíyèsi i, ìwọ sá ti kọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn,
    ìwọ ṣá ti mú ọwọ́ aláìlera le.
Ọ̀rọ̀ rẹ ti gbé àwọn tí ń ṣubú lọ dúró,
    ìwọ sì ti mú eékún àwọn tí ń wárìrì lera.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ó dé bá ọ, ó sì rẹ̀ ọ́, ó kọlù ọ́;
    ara rẹ kò lélẹ̀.
Ìbẹ̀rù Ọlọ́run rẹ kò ha jẹ́ ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ
    àti ìdúró ọ̀nà rẹ kò ha sì jẹ́ ìrètí rẹ?

“Èmi bẹ̀ ọ́ rántí: Ta ni ó ṣègbé rí láìṣẹ̀?
    Tàbí níbo ni a gbé gé olódodo kúrò rí?
Àní bí èmi ti rí i pé, àwọn tí ń ṣe ìtulẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀,
    tí wọ́n sì fún irúgbìn ìwà búburú, wọn a sì ká èso rẹ̀ náà.
Nípa ìfẹ́ sí Ọlọ́run wọn a ṣègbé,
    nípa èémí ìbínú rẹ̀ wọn a parun.
10 Bíbú ramúramù kìnnìún àti ohùn òǹrorò kìnnìún
    àti eyín àwọn ẹgbọrọ kìnnìún ní a ká.
11 Kìnnìún kígbe, nítorí àìrí ohun ọdẹ,
    àwọn ẹgbọrọ kìnnìún sísanra ni a túká kiri.

12 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí a fi ohun àṣírí kan hàn fún mi,
    etí mi sì gbà díẹ̀ nínú rẹ̀.
13 Ní ìrò inú lójú ìran òru,
    nígbà tí oorun èjìká kùn ènìyàn.
14 Ẹ̀rù bà mí àti ìwárìrì
    tí ó mú gbogbo egungun mi jí pépé.
15 Nígbà náà ni ẹ̀mí kan kọjá lọ ní iwájú mi,
    irun ara mi dìde dúró ṣánṣán.
16 Ó dúró jẹ́ẹ́,
    ṣùgbọ́n èmi kò le wo àpẹẹrẹ ìrí rẹ̀,
àwòrán kan hàn níwájú mi,
    ìdákẹ́rọ́rọ́ wà, mo sì gbóhùn kan wí pé:
17 ‘Ẹni kíkú le jẹ́ olódodo ju Ọlọ́run,
    ènìyàn ha le mọ́ ju Ẹlẹ́dàá rẹ̀ bí?
18 Kíyèsi i, òun kò gbẹ́kẹ̀lé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀,
    nínú àwọn angẹli rẹ̀ ní ó sì rí ẹ̀ṣẹ̀.
19 Mélòó mélòó àwọn tí ń gbé inú ilé amọ̀,
    ẹni tí ìpìlẹ̀ wọ́n jásí erùpẹ̀
    tí yóò di rírun kòkòrò.
20 A pa wọ́n run láàrín òwúrọ̀ àti àṣálẹ́
    wọ́n sì parun títí láé, láìrí ẹni kà á sí.
21 A kò ha ké okùn iye wọ́n kúrò bí?
    Wọ́n kú, àní láìlọ́gbọ́n?’

Ìṣe àwọn Aposteli 7:44-60

44 (A)“Àwọn baba wa ní àgọ́ ẹ̀rí pẹ̀lú wọn ní ijù. Èyí tí a ṣe gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run tí ó ba Mose sọ̀rọ̀ pé kí ó ṣe é, gẹ́gẹ́ bí àpẹẹrẹ tí ó ti rí. 45 (B)Ti àwọn baba wa tí ó tẹ̀lé wọn sí mú bá Joṣua wá sí ilẹ̀ ìní àwọn aláìkọlà, tí Ọlọ́run lè jáde kúrò níwájú àwọn baba wa, títí dí àkókò Dafidi. 46 (C)Ẹni tí ó rí ojúrere níwájú Ọlọ́run, tí ó sì tọrọ láti rí ibùgbé fún Ọlọ́run Jakọbu. 47 (D)Ṣùgbọ́n Solomoni ni ó kọ́ ilé fún un.

48 “Ṣùgbọ́n Ọ̀gá-ògo kì í gbé ilé ti a fi ọwọ́ kọ́: gẹ́gẹ́ bí wòlíì ti wí pé:

49 (E)“ ‘Ọ̀run ni ìtẹ́ mi,
    ayé ni àpótí ìtìsẹ̀ mi.
Irú ilé kín ní ẹ̀yin yóò kọ́ fún mi?
    ni Olúwa wí.
    Tàbí níbo ni yóò jẹ́ ibi ìsinmi mi?
50 Ọwọ́ mi kò ha ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí.’

51 (F)“Ẹ̀yin ọlọ́rùn líle àti aláìkọlà àyà àti etí! Bí àwọn baba yín gẹ́lẹ́ ni ẹ̀yin rí: Nígbà gbogbo ni ẹ̀yin máa ń dènà Ẹ̀mí Mímọ́! 52 Ǹjẹ́ ọ̀kan tilẹ̀ wà nínú àwọn wòlíì tí àwọn baba yín kò ṣe inúnibíni sí? Wọn sì ti pa àwọn ti ó ti ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa wíwá Ẹni Olódodo náà. Nísinsin yìí ẹ̀yin ti dalẹ̀ rẹ̀ ẹ̀yin sí ti pa. 53 Ẹ̀yin tí ó gba òfin, gẹ́gẹ́ bí àwọn angẹli ti fi fún ni, tí ẹ kò sì pa á mọ́.”

A sọ Stefanu ní òkúta pa

54 Nígbà tí wọn sì gbọ́ nǹkan wọ̀nyí ọkàn wọn gbọgbẹ́ dé inú, wọn sì payínkeke sí i. 55 Ṣùgbọ́n Stefanu, ẹni tí ó kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, ó tẹjúmọ́ ọ̀run, ó sì rí ògo Ọlọ́run, àti Jesu dúró ní ọwọ́ ọ̀tún Ọlọ́run. 56 Ó sì wí pé, “Wò ó, mo rí ọ̀run ṣí sílẹ̀, Ọmọ Ènìyàn sì dúró ní ọwọ́ ọ̀tún Ọlọ́run.”

57 Nígbà náà ni wọn kígbe ní ohùn rara, wọn sí di etí wọ́n, gbogbo wọn sì sáré sí i, wọ́n sì rọ́ lù ú, 58 wọ́n sì wọ́ ọ sẹ́yìn òde ìlú, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sísọ ọ́ ní òkúta; àwọn ẹlẹ́rìí sì fi aṣọ wọn lélẹ̀ lẹ́sẹ̀ ọmọkùnrin kan tí a ń pè ní Saulu.

59 Bí wọ́n ti ń sọ Stefanu ní òkúta, ó sì ké pe Olúwa wí pé, “Jesu Olúwa, gba ẹ̀mí mi.” 60 Nígbà náà ni ó wólẹ̀ lórí eékún rẹ̀, ó kígbe sókè pé, “Olúwa, má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀ yìí sí wọn ní ọrùn.” Nígbà ti ó sì wí èyí tán, ó sùn lọ.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)

Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.