Print Page Options
Previous Prev Day Next DayNext

Old/New Testament

Each day includes a passage from both the Old Testament and New Testament.
Duration: 365 days
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Version
Jobu 38-40

Ọlọ́run pe Jobu níjà

38 Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àjàyíká wá, ó sì wí pé:

“Ta ni èyí tí ń fi ọ̀rọ̀ àìlóye
    láti fi ṣókùnkùn bo ìmọ̀ mi?
Di ẹ̀gbẹ́ ara rẹ ní àmùrè bí ọkùnrin nísinsin yìí,
    nítorí pé èmi yóò béèrè lọ́wọ́ rẹ
    kí o sì dá mi lóhùn.

“Níbo ni ìwọ wà nígbà tí mo fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀?
    Wí bí ìwọ bá mòye.
Ta ni ó fi ìwọ̀n rẹ lélẹ̀, dájú bí ìwọ bá mọ̀ ọ́n?
    Tàbí ta ni ó ta okùn wíwọ̀n sórí rẹ?
Lórí ibo ni a gbé kan ìpìlẹ̀ rẹ̀ mọ́,
    tàbí ta ni ó fi òkúta igun rẹ̀ lélẹ̀,
Nígbà náà àwọn ìràwọ̀ òwúrọ̀ jùmọ̀ kọrin pọ̀,
    tí gbogbo àwọn ọmọ Ọlọ́run hó ìhó ayọ̀?

“Tàbí ta ni ó fi ìlẹ̀kùn sé omi Òkun mọ́,
    nígbà tí ó ya padà bí ẹni pé ó ti inú jáde wá,
Nígbà tí mo fi àwọsánmọ̀ ṣe aṣọ rẹ̀,
    tí mo sì fi òkùnkùn biribiri ṣe ọ̀já ìgbà inú rẹ̀,
10 Nígbà tí mo ti pàṣẹ ìpinnu mi fún un,
    tí mo sì ṣe bèbè àti ìlẹ̀kùn,
11 Tí mo sì wí pé níhìn-ín ni ìwọ ó dé, kí o má sì rékọjá,
    níhìn-ín sì ni ìgbéraga rẹ yóò gbé dúró mọ?

12 “Ìwọ pàṣẹ fún òwúrọ̀ láti ìgbà ọjọ́ rẹ̀ wá,
    ìwọ sì mú ìlà-oòrùn mọ ipò rẹ̀,
13 Kí ó lè di òpin ilẹ̀ ayé mú,
    ki a lè gbọ́n àwọn ènìyàn búburú kúrò nínú rẹ̀?
14 Kí ó yí padà bí amọ̀ fún èdìdì amọ̀,
    kí gbogbo rẹ̀ kí ó sì fi ara rẹ̀ hàn bí ẹni pé nínú aṣọ ìgúnwà.
15 A sì fa ìmọ́lẹ̀ wọn sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ ènìyàn búburú,
    apá gíga ni a sì ṣẹ́.

16 “Ìwọ ha wọ inú ìsun Òkun lọ rí bí?
    Ìwọ sì rìn lórí ìsàlẹ̀ ibú ńlá?
17 A ha ṣílẹ̀kùn ikú sílẹ̀ fún ọ rí bí,
    ìwọ sì rí ìlẹ̀kùn òjìji òkú?
18 Ìwọ mòye ìbú ayé bí?
    Sọ bí ìwọ bá mọ gbogbo èyí.

19 “Ọ̀nà wo ni ìmọ́lẹ̀ ń gbé?
    Bí ó ṣe ti òkùnkùn, níbo ni ipò rẹ̀,
20 Tí ìwọ í fi mú un lọ sí ibi àlá rẹ̀,
    tí ìwọ ó sì le mọ ipa ọ̀nà lọ sínú ilé rẹ̀?
21 Ìwọ mọ èyí, nítorí nígbà náà ni a bí ọ?
    Iye ọjọ́ rẹ sì pọ̀.

22 “Ìwọ ha wọ inú ìṣúra ìdì òjò lọ rí bí,
    ìwọ sì rí ilé ìṣúra yìnyín rí,
23 Tí mo ti fi pamọ́ de ìgbà ìyọnu,
    dé ọjọ́ ogun àti ìjà?
24 Ọ̀nà wo ni ó lọ sí ibi tí ìmọ́lẹ̀ fi ń la,
    tí afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn ń tàn káàkiri lórí ilẹ̀ ayé?
25 Ta ni ó la ipadò fún ẹ̀kún omi,
    àti ọ̀nà fún mọ̀nàmọ́ná àrá,
26 láti mú u rọ̀jò sórí ayé níbi tí ènìyàn kò sí,
    ní aginjù níbi tí ènìyàn kò sí;
27 láti mú ilẹ̀ tútù, ijù àti aláìro
    láti mú àṣẹ̀ṣẹ̀yọ ewéko rú jáde?
28 Òjò ha ní baba bí?
    Tàbí ta ni o bí ìkún ìṣe ìrì?
29 Láti inú ta ni ìdì omi ti jáde wá?
    Ta ni ó bí ìrì dídì ọ̀run?
30 Nígbà tí omi di líle bí òkúta,
    nígbà tí ojú ibú ńlá sì dìpọ̀.

31 “Ìwọ ha le fi ọ̀já de àwọn ìràwọ̀ Pleiadesi dáradára?
    Tàbí ìwọ le tún di Ìràwọ̀ Orioni?
32 Ìwọ le mú àwọn ààmì méjìlá ìràwọ̀ Masaroti jáde wá nígbà àkókò wọn?
    Tàbí ìwọ le ṣe amọ̀nà Beari pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀?
33 Ǹjẹ́ ìwọ mọ ìlànà ọ̀run?
    Ìwọ le fi ìjọba Ọlọ́run lélẹ̀ lórí ayé?

34 “Ìwọ le gbé ohùn rẹ sókè dé àwọsánmọ̀
    kí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi kí ó lè bò ọ́?
35 Ìwọ le rán mọ̀nàmọ́ná kí wọn kí ó le lọ,
    ní ọ̀nà wọn kí wọn kí ó sì wí fún wọn pé, ‘àwa nìyí’?
36 Ta ni ó fi ọgbọ́n pamọ́ sí odò ikùn
    tàbí tí ó fi òye sínú àyà?
37 Ta ni ó fi ọgbọ́n ka iye àwọsánmọ̀?
    Ta ni ó sì mú ìgò ọ̀run dà jáde,
38 Nígbà tí erùpẹ̀ di líle,
    àti ògúlùtu dìpọ̀?

39 “Ìwọ ha dẹ ọdẹ fún abo kìnnìún bí?
    Ìwọ ó sì tẹ ebi ẹgbọrọ kìnnìún lọ́rùn,
40 Nígbà tí wọ́n bá mọ́lẹ̀ nínú ihò
    tí wọ́n sì ba ní ibùba de ohun ọdẹ?
41 Ta ni ó ń pèsè ohun jíjẹ fún ẹyẹ ìwò,
    nígbà tí àwọn ọmọ rẹ ń ké pe Ọlọ́run,
    tí wọ́n sì máa ń fò kiri nítorí àìní ohun jíjẹ?

Agbára Ọlọ́run

39 “Ìwọ mọ àkókò ìgbà tí àwọn ewúrẹ́ orí àpáta ń bímọ?
    Ìwọ sì lè kíyèsi ìgbà tí abo àgbọ̀nrín ń bímọ?
Ìwọ lè ka iye òṣùpá tí wọn ń pé,
    ìwọ sì mọ àkókò ìgbà tí wọn ń bímọ,
Wọ́n tẹ ara wọn ba, wọ́n bímọ,
    wọ́n sì mú ìkáàánú wọn jáde.
Àwọn ọmọ wọn rí dáradára, wọ́n dàgbà nínú ọ̀dàn;
    wọ́n jáde lọ, wọn kò sì tún padà wá sọ́dọ̀ wọn.

“Ta ni ó jọ̀wọ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ oko lọ́wọ́?
    Tàbí ta ní ó tú ìdè kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó,
Èyí tí mo fi aginjù ṣe ilé fún,
    àti ilẹ̀ iyọ̀ ní ibùgbé rẹ̀.
Ó rẹ́rìn-ín sí ariwo ìlú,
    bẹ́ẹ̀ ni òun kò sì gbọ́ igbe darandaran.
Orí àtòlé òkè ńlá ni ibùjẹ oko rẹ̀,
    Òun a sì máa wá ewé tútù gbogbo rí.

“Àgbáǹréré ha jẹ́ sìn ọ́ bí?
    Tàbí ó jẹ́ dúró ní ibùjẹ ẹran rẹ ní òru?
10 Ìwọ le fi Òkun tata de àgbáǹréré nínú aporo?
    Tàbí ó jẹ́ máa fa ìtulẹ̀ nínú aporo oko tọ̀ ọ́ lẹ́yìn?
11 Ìwọ ó gbẹ́kẹ̀lé e nítorí agbára rẹ̀ pọ̀?
    Ìwọ ó sì fi iṣẹ́ rẹ lé e lọ́wọ́?
12 Ìwọ le gbẹ́kẹ̀lé pé, yóò mú èso oko rẹ̀ wá sílé,
    àti pé yóò sì kó ọ jọ sínú àká rẹ?

13 “Ìwọ ni yóò ha fi ìyẹ́ dáradára fún ọ̀kín bí,
    tàbí ìyẹ́ àti ìhùhù bo ògòǹgò?
14 Ó yé ẹ̀yìn rẹ̀ sílẹ̀ lórí ilẹ̀,
    a sì mú wọn gbóná nínú ekuru;
15 Tí ó sì gbàgbé pé, ẹsẹ̀ lè tẹ̀ wọ́n fọ́,
    tàbí pé ẹranko igbó lè tẹ̀ wọ́n fọ́.
16 Kò ní àánú sí àwọn ọmọ rẹ̀ bí ẹni pé wọn kì í ṣe tirẹ̀;
    asán ni iṣẹ́ rẹ̀ láìní ìbẹ̀rù;
17 Nítorí pé Ọlọ́run kò fún un ní ọgbọ́n,
    bẹ́ẹ̀ ni kò sì fi ìpín òye fún un.
18 Nígbà tí ó gbé ara sókè,
    ó gan ẹṣin àti ẹlẹ́ṣin.

19 “Ìwọ ni ó fi agbára fún ẹṣin bí,
    tàbí ṣé ìwọ ni ó fi gọ̀gọ̀ wọ ọrùn rẹ̀ ní aṣọ?
20 Ìwọ le mú fò sókè bí ẹlẹ́ǹgà?
    Ògo èémí imú rẹ ní ẹ̀rù ńlá.
21 Ó fi ẹsẹ̀ halẹ̀ nínú Àfonífojì, ó sì yọ̀ nínú agbára rẹ̀;
    ó lọ jáde láti pàdé àwọn ìhámọ́ra ogun.
22 Ó fi ojú kékeré wo ẹ̀rù, àyà kò sì fò ó;
    bẹ́ẹ̀ ni kì í sì í padà sẹ́yìn kúrò lọ́wọ́ idà.
23 Lọ́dọ̀ rẹ ni apó-ọfà ń mì pẹ́kẹ́pẹ́kẹ́,
    àti ọ̀kọ̀ dídán àti àpáta.
24 Ó fi kíkorò ojú àti ìbínú ńlá gbé ilé mi,
    bẹ́ẹ̀ ni òun kò sì gbà á gbọ́ pé, ìró ìpè ni.
25 Ó wí nígbà ìpè pé, Háà! Háà!
    Ó sì gbóhùn ogun lókèèrè réré,
    igbe àwọn balógun àti ìhó ayọ̀ ogun wọn.

26 “Àwòdì ha máa ti ipa ọgbọ́n rẹ̀ fò sókè,
    tí ó sì na ìyẹ́ apá rẹ̀ sí ìhà gúúsù?
27 Idì ha máa fi àṣẹ rẹ̀ fò sókè,
    kí ó sì lọ tẹ́ ìtẹ́ rẹ̀ sí òkè gíga?
28 Ó ń gbé, ó sì ń wò ní orí àpáta,
    lórí pàlàpálá òkúta àti ibi orí òkè.
29 Láti ibẹ̀ lọ ni ó ti ń wá oúnjẹ kiri,
    ojú rẹ̀ sì ríran rí òkè réré.
30 Àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú a máa mu ẹ̀jẹ̀,
    níbi tí òkú bá gbé wà, níbẹ̀ ni òun wà pẹ̀lú.”

Jobu rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀

40 Olúwa dá Jobu lóhùn sí pẹ̀lú, ó sì wí pé:

“Ẹni tí ń bá Olódùmarè wíjọ́ yóò ha kọ ní ẹ̀kọ́?
    Ẹni tí ń bá Ọlọ́run wí jẹ́ kí ó dáhùn!”

Nígbà náà ni Jobu dá Olúwa lóhùn wá ó sì wí pé,

“Kíyèsi i, ẹ̀gbin ni èmi—ohun kí ni èmi ó dà?
    Èmi ó fi ọwọ́ mi le ẹnu mi.
Ẹ̀ẹ̀kan ní mo sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n èmi kì yóò tún sọ mọ́;
    lẹ́ẹ̀kejì ni, èmi kò sì le ṣe é mọ́.”

Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àyíká wá, ó sì wí pé:

“Di àmùrè gírí ní ẹgbẹ́ rẹ bí ọkùnrin,
    èmi ó bi ọ léèrè,
    kí ìwọ kí ó sì dá mi lóhùn.

“Ìwọ ha fẹ́ mú ìdájọ́ mi di asán?
    Ìwọ ó sì dá mi lẹ́bi, kí ìwọ lè ṣe olódodo
Ìwọ ni apá bí Ọlọ́run
    tàbí ìwọ lè fi ohùn sán àrá bí òun?
10 Fi ọláńlá àti ọlá ìtayọ rẹ̀ ṣe ara rẹ ní ọ̀ṣọ́,
    tí ó sì fi ògo àti títóbi ọ̀ṣọ́ bo ara ní aṣọ.
11 Mú ìrunú ìbínú rẹ jáde;
    kíyèsí gbogbo ìwà ìgbéraga rẹ kí o sì rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
12 Wo gbogbo ìwà ìgbéraga, ènìyàn kí o sì rẹ ẹ sílẹ̀
    kí o sì tẹ ènìyàn búburú mọ́lẹ̀ ní ipò wọn.
13 Sin gbogbo wọn papọ̀ nínú erùpẹ̀,
    kí o sì di ojú ìkọ̀kọ̀ wọn ní isà òkú
14 Nígbà náà ní èmi ó yìn ọ́ pé,
    ọwọ́ ọ̀tún ara rẹ lè gbà ọ́ là.

15 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí kíyèsi Behemoti,
    tí mo dá pẹ̀lú rẹ,
    òun a máa jẹ koríko bí ọ̀dá màlúù.
16 Wò o nísinsin yìí, agbára rẹ wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ,
    àti ipa rẹ nínú ìṣàn ìkún rẹ.
17 Òun a máa jù ìrù rẹ̀ bí i igi kedari;
    Iṣan itan rẹ̀ dìjọ pọ̀.
18 Egungun rẹ̀ ní ògùṣọ̀ idẹ;
    Egungun rẹ̀ dàbí ọ̀pá irin.
19 Òun ni olórí nínú àwọn iṣẹ́ Ọlọ́run;
    síbẹ̀ Ẹlẹ́dàá rẹ̀ fi idà rẹ̀ lé e lọ́wọ́.
20 Nítòótọ́ òkè ńláńlá ní i mu ohun jíjẹ fún un wá,
    níbi tí gbogbo ẹranko igbó máa ṣiré ní ẹ̀gbẹ́ ibẹ̀.
21 Ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi lótusì,
    lábẹ́ eèsún àti ẹrẹ̀.
22 Igi lótusì ṣíji wọn bò o;
    igi arọrọ odò yí i káàkiri.
23 Kíyèsi i, odò ńlá sàn jọjọ, òun kò sálọ;
    ó wà láìléwu bí ó bá ṣe pé odò Jordani ti ṣàn lọ sí ẹnu rẹ̀.
24 Ẹnìkan ha lè mú un ní ojú rẹ̀,
    tàbí dẹkùn fún tàbí a máa fi ọ̀kọ̀ gún imú rẹ̀?

Ìṣe àwọn Aposteli 16:1-21

Timotiu darapọ̀ mọ́ Paulu àti Sila

16 Ó sì wá sí Dabe àti Lysra: sí kíyèsi i, ọmọ-ẹ̀yìn kan wà níbẹ̀, tí a ń pè ní Timotiu, ọmọ obìnrin kan tí í ṣe Júù, tí ó gbàgbọ́; ṣùgbọ́n Giriki ní baba rẹ̀. Ẹni tí a ròhìn rẹ̀ ní rere lọ́dọ̀ àwọn arákùnrin tí ó wà ní Lysra àti Ikoniomu. Òun ni Paulu fẹ́ kí ó bá òun lọ; ó sì mú un, ó sì kọ ọ́ ní ilà, nítorí àwọn Júù tí ó wà ní agbègbè wọ̀nyí: nítorí gbogbo wọn mọ̀ pé, Giriki ni baba rẹ̀. Bí wọn sì ti ń la àwọn ìlú lọ, wọ́n ń fi àwọn àṣẹ, tí a tí pinnu láti ọ̀dọ̀ àwọn aposteli àti àwọn alàgbà tí ó wà ní Jerusalẹmu, lé wọn lọ́wọ́ láti máa pa wọ́n mọ́. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìjọ sì fẹsẹ̀múlẹ̀ ní ìgbàgbọ́, wọn sí ń pọ̀ sí i ní iye lójoojúmọ́.

Ìran Paulu nípa arákùnrin Makedonia

Wọ́n sì la agbègbè Frigia já, àti Galatia, nítorí tí Ẹ̀mí Mímọ́ kọ̀ fún wọn láti sọ ọ̀rọ̀ náà ni Asia. Nígbà tí wọ́n dé ọ̀kánkán Misia, wọ́n gbìyànjú láti lọ sí Bitinia, ṣùgbọ́n Ẹ̀mí Jesu kò gbà fún wọn. Nígbà tí wọ́n sì kọjá lẹ́bàá Misia, wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ sí Troasi. Ìran kan si hàn sì Paulu ni òru: Ọkùnrin kan ará Makedonia dúró, ó sì ń bẹ̀ ẹ́, wí pé, “Rékọjá wá sí Makedonia, kí o sí ràn wá lọ́wọ́!” 10 Nígbà tí ó sì tí rí ìran náà, lọ́gán ó múra láti lọ sí Makedonia, a ka á sí pé, Ọlọ́run tí pè wá láti wàásù ìhìnrere fún wọn.

Ìyípadà Lidia ní Filipi

11 Nítorí náà nígbà tí àwa ṣíkọ̀ ní Troasi a ba ọ̀nà tààrà lọ sí Samotrakea, ni ọjọ́ kejì a sì dé Neapoli; 12 Láti ibẹ̀ àwa sì lọ si Filipi, tí í ṣe ìlú Makedonia, olú ìlú ìhà ibẹ̀, ìlú lábẹ́ Romu, àwa sì jókòó ní ìlú yìí fún ọjọ́ mélòókan.

13 Lọ́jọ́ ìsinmi, àwa sí jáde lọ sí ẹ̀yìn odi ìlú náà, lẹ́bàá odò kan, níbi tí a rò pé ibi àdúrà wà; àwa sí jókòó, a sì bá àwọn obìnrin tí o péjọ sọ̀rọ̀. 14 Àti obìnrin kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Lidia, elése àlùkò, ará ìlú Tiatira, ẹni tí ó sin Ọlọ́run, ó gbọ́ ọ̀rọ̀ wa, ọkàn ẹni tí Olúwa ṣí láti fetísí ohun tí a tí ẹnu Paulu sọ. 15 Nígbà tí a sí bamitiisi rẹ̀, àti àwọn ara ilé rẹ̀, ó bẹ̀ wá, wí pé, “Bí ẹ̀yin bá kà mí ni olóòtítọ́ sí Olúwa, ẹ wá si ilé mi, kí ẹ sí wọ̀ níbẹ̀!” O sí rọ̀ wá.

Paulu àti Sila nínú túbú

16 Bí àwa tí n lọ sí ibi àdúrà náà, ọmọbìnrin kan tí o ní ẹ̀mí àfọ̀ṣẹ, pàdé wa, ẹni tí ó fi àfọ̀ṣẹ mú èrè púpọ̀ wá fún àwọn ọ̀gá rẹ̀: 17 Òun náà ni ó ń tọ Paulu àti àwa lẹ́hìn, ó sì ń kígbe, pé, “Àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ni ìránṣẹ́ Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, tí ń kéde ọ̀nà ìgbàlà fún yin!” 18 Ó sì ń ṣe èyí lọ́jọ́ púpọ̀, ṣùgbọ́n nígbà tí inú Paulu bàjẹ́, tí ó sì yípadà, ó wí fún ẹ̀mí náà pé, “Mo pàṣẹ fún ọ ní orúkọ Jesu Kristi kí o jáde kúrò lára rẹ̀!” Ó sí jáde ni wákàtí kan náà.

19 Nígbà tí àwọn ọ̀gá rẹ̀ sì rí i pé, ìgbẹ́kẹ̀lé èrè wọn pin, wọ́n mú Paulu àti Sila, wọn sì wọ́ wọn lọ sí ọjà tọ àwọn aláṣẹ lọ; 20 Nígbà tí wọ́n sì mú wọn tọ àwọn onídàájọ́ lọ, wọ́n wí pé, “Àwọn ọkùnrin wọ̀nyí tí í ṣe Júù, wọ́n ń yọ ìlú wa lẹ́nu jọjọ; 21 Wọ́n sì ń kọ́ni ní àṣà tí kò yẹ fún wa, àwa ẹni tí í ṣe ara Romu, láti gbà àti láti tẹ̀lé.”

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)

Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.