Print Page Options
Previous Prev Day Next DayNext

Chronological

Read the Bible in the chronological order in which its stories and events occurred.
Duration: 365 days
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Version
Isaiah 28-30

Ègbé ni fún Efraimu

28 Ègbé ni fún adé ìgbéraga,
    fún àwọn ọ̀mùtí Efraimu,
àti fún ìtànná rírọ, ẹwà ògo rẹ̀,
    tí ó tò sí orí àfonífojì ẹlẹ́tù lójú
    àti sí ìlú náà
    ìgbéraga àwọn tí ọtí wáìnì ń pa tí a rẹ̀ sílẹ̀
Kíyèsi i, Olúwa ní ẹnìkan tí ó le, tí ó sì lágbára,
    gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ yìnyín àti bí ìjì apanirun,
gẹ́gẹ́ bí àrọ̀dá òjò àti òjò tí ó mú ìkún omi wá,
    òun yóò fi tipátipá sọ ọ́ sílẹ̀.
Adé ìgbéraga àwọn ọ̀mùtí Efraimu,
    ni a ó fi ẹsẹ̀ tẹ̀ mọ́lẹ̀.
Òdòdó tí ó ń rọ náà tí í ṣe ẹwà ògo rẹ̀,
    tí ó tò sí orí àfonífojì ẹlẹ́tù lójú,
yóò dàbí èso ọ̀pọ̀tọ́ tí ó pọ́n ṣáájú ìkórè
    bí ẹnikẹ́ni bá ti rí i tí ó sì mú un ní ọwọ́ rẹ̀,
    òun a sì mì ín.

Ní ọjọ́ náà Olúwa àwọn ọmọ-ogun
    yóò jẹ́ adé tí ó lógo,
àti adé tí ó lẹ́wà
    fún àwọn ènìyàn rẹ̀ tí ó ṣẹ́kù.
Òun yóò sì jẹ́ ẹ̀mí ìdájọ́ òdodo
    fún ẹni tí ó jókòó ní ìtẹ́ ìdájọ́
àti orísun agbára
    fún àwọn ẹni tí ó ń dá ogun padà ní ẹnu ibodè.

Àwọn wọ̀nyí pẹ̀lú ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n fún ọtí wáìnì
    wọ́n pòòrì fún ọtí líle,
Àwọn àlùfáà àti wòlíì ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n fún ọtí líle
    wọ́n ta gíẹ́ gíẹ́ fún ọtí wáìnì
wọ́n ń lọ́ bìrì bìrì fún ọtí líle,
    wọ́n ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n nígbà tí wọ́n ń ríran,
    wọ́n kọsẹ̀ nígbà tí wọ́n ń mú ìpinnu wá.
Gbogbo orí tábìlì ni ó kún fún èébì
    kò sì ṣí ibìkan tí kò sí ẹ̀gbin.

“Ta ni ẹni náà tí ó ń gbìyànjú àti kọ́?
    Ta ni ó sì ń ṣàlàyé ìròyìn in rẹ̀ fún?
Sí àwọn ọmọdé tí a já lẹ́nu ọmú wọn,
    sí àwọn tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ gbà lẹ́nu ọmú.
10 Nítorí tí í ṣe: báyìí ni orí
    Ṣe, kí o si túnṣe, ṣe kí o si túnṣe,
àṣẹ n gorí àṣẹ, àṣẹ n gorí àṣẹ
    díẹ̀ níhìn-ín, díẹ̀ lọ́hùn.”

11 (A)Ó dára báyìí, pẹ̀lú ètè àjèjì àti ahọ́n àìmọ̀
    Ọlọ́run yóò bá àwọn ènìyàn yìí sọ̀rọ̀
12 (B)àwọn tí ó sọ fún wí pé,
    “Èyí ni ibi ìsinmi, jẹ́ kí àwọn aláàárẹ̀ sinmi”;
àti pé, “èyí ni ibi ìsinmi”
    ṣùgbọ́n wọn kò tẹ́tí sílẹ̀.
13 Fún ìdí èyí, ọ̀rọ̀ Olúwa sí wọn yóò di pé
    Ṣe, kí o si túnṣe, ṣe kí o si túnṣe,
àṣẹ n gorí àṣẹ, àṣẹ n gorí àṣẹ
    díẹ̀ níhìn-ín, díẹ̀ lọ́hùn
bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò lọ tí wọn yóò tún ṣubú sẹ́yìn,
    wọn yóò fi ara pa, wọn yóò bọ́ sínú okùn
    a ó sì gbá wọn mú.

14 Nítorí náà, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ẹlẹ́gàn,
    tí ń jẹ ọba lórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí ní Jerusalẹmu.
15 Ẹ fọ́n pé, “Àwa ti bá ikú mulẹ̀,
    pẹ̀lú ibojì ni àwa ti jọ ṣe àdéhùn.
Nígbà tí ìbáwí gbígbóná fẹ́ kọjá,
    kò le kàn wá lára,
nítorí a ti fi irọ́ ṣe ààbò o wa
    àti àìṣòótọ́ ibi ìpamọ́ wa.”

16 (C)Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí:

“Kíyèsi i, èmi gbé òkúta kan lélẹ̀ ní Sioni, òkúta tí a dánwò,
    òkúta igun ilé iyebíye fún ìpìlẹ̀ tí ó dájú;
ẹnikẹ́ni tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé
    kì yóò ní ìfòyà.
17 Èmi yóò fi ìdájọ́ ṣe okùn òṣùwọ̀n
    àti òdodo òjé òṣùwọ̀n;
yìnyín yóò gbá ààbò yín dànù àti irọ́,
    omi yóò sì kún bo gbogbo ibi tí
    ẹ ń fi ara pamọ́ sí mọ́lẹ̀.
18 Májẹ̀mú yín tí ẹ bá ikú dá ni a ó fa igi lé;
    àdéhùn yín pẹ̀lú ibojì ni kì yóò dúró.
Nígbà tí ìbínú gbígbóná náà bá fẹ́ kọjá,
    a ó ti ipa rẹ̀ lù yín bolẹ̀.
19 Nígbàkúgbà tí ó bá ti wá ni
    yóò máa gbé ọ lọ,
ni àràárọ̀, ní ọ̀sán àti ní òru,
    ni yóò máa fẹ́ kọjá lọ.”

Ìmòye ọ̀rọ̀-ìmọ̀ yìí
    yóò máa mú ìpayà ńlá wá.
20 Ibùsùn kúrú púpọ̀ fún ìnara lé lórí,
    ìbora kò fẹ̀ tó láti yí ara yín ká.
21 Olúwa yóò dìde sókè gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe
    ní òkè Peraṣimu
yóò ru ara rẹ̀ sókè gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe
    ní Àfonífojì Gibeoni—
láti ṣe iṣẹ́ rẹ̀, abàmì iṣẹ́ ẹ rẹ̀,
    yóò ṣe iṣẹ́ rẹ̀, àní àjèjì iṣẹ́ rẹ̀.
22 Ní ìsinsin yìí ẹ dákẹ́ ẹlẹ́yà ṣíṣe,
    bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìdè e yín yóò le sí i;
Olúwa, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti sọ fún mi
    nípa àṣẹ ìparun ti ó ti pa lórí gbogbo ilẹ̀ náà.

23 Tẹ́tí kí o sì gbọ́ ohùn mi,
    fi ara balẹ̀ kí o sì gbọ́ ohun tí mo sọ.
24 Nígbà tí àgbẹ̀ kan bá tu ilẹ̀ láti gbìn
    yóò ha máa tulẹ̀ títí bi?
Ǹjẹ́ yóò ha máa tu ilẹ̀ kí
    ó sì máa jọ̀ ọ́ títí lọ bí?
25 Nígbà tí òun bá ti tẹ́ ojú ilẹ̀ rẹ̀ pẹrẹsẹ
    òun kò ha ń fúnrúgbìn dílì
kí ó sì fúnrúgbìn kummini ká?
    Kí ó sì gbin alikama lẹ́sẹẹsẹ,
barle tí a yàn,
    àti spelti ní ipò rẹ̀?
26 Ọlọ́run rẹ̀ tọ́ ọ ṣọ́nà
    ó sì kọ́ ọ lẹ́kọ̀ọ́ ní ọ̀nà tó tọ́.

27 Nítorí a kò fi ohun èlò ìpakà dili,
    bẹ́ẹ̀ ni a kì í yí kẹ̀kẹ́ ẹrù kiri lórí kummini;
ṣùgbọ́n ọ̀pá ni a fi ń pa dili jáde,
    ọ̀gọ ni a sì lu kummini.
28 A gbọdọ̀ lọ ìyẹ̀fun kí a tó ṣe àkàrà;
    bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kì í máa pa á lọ títí láé.
Bí ó tilẹ̀ yí ẹsẹ̀ kẹ̀kẹ́ ìpakà a rẹ̀ lórí i rẹ̀,
    àwọn ẹṣin rẹ̀ kò le lọ̀ ọ́.
29 Gbogbo èyí pẹ̀lú ti ọ̀dọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun wá,
    oníyanu ní ìmọ̀ràn àti ológo ní ọgbọ́n.

Ègbé ni fún ìlú Dafidi

29 Ègbé ni fún ọ, Arieli, Arieli,
    ìlú níbi tí Dafidi tẹ̀dó sí!
Fi ọdún kún ọdún
    sì jẹ́ kí àwọn àkọlùkọgbà àjọ̀dún un rẹ tẹ̀síwájú.
Síbẹ̀síbẹ̀ èmi yóò dó ti Arieli
    òun yóò ṣọ̀fọ̀ yóò sì sọkún,
    òun yóò sì dàbí pẹpẹ ọkàn sí mi.
Èmi yóò sì wà ní bùba yí ọ ká níbi gbogbo;
    Èmi yóò sì fi ilé ìṣọ́ yí ọ ká:
    èmi yóò sì fi iṣẹ́ ìdó ti ni mi dojúkọ ọ́.
Ní ìrẹ̀sílẹ̀, ìwọ ó sì máa sọ̀rọ̀ láti ilẹ̀ wá;
    ọ̀rọ̀ rẹ yóò sì máa kùn jáde láti inú erùpẹ̀.
Ohun rẹ yóò máa jáde bí i ti ẹnìkan tó ní ẹ̀mí àfọ̀ṣẹ láti ilẹ̀ jáde wá,
    láti inú erùpẹ̀ ni ohùn rẹ
    yóò máa wá wúyẹ́wúyẹ́.

Ṣùgbọ́n àwọn ọ̀tá rẹ, yóò dàbí yanrìn kíkúnná,
    agbo àwọn aláìláàánú bí ìyàngbò tí a fẹ́ dànù.
    Lójijì, ní ìṣẹ́jú kan,
Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò wá
    pẹ̀lú àrá, ilẹ̀-rírì àti ariwo ńlá
àti ẹ̀fúùfù líle àti iná ajónirun
    Lẹ́yìn náà,
    ọ̀gọ̀ọ̀rọ̀ ènìyàn tí gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó bá Arieli jà,
tí ó dojú ìjà kọ òun àti ilé olódi rẹ̀
    tí ó sì dó tì í,
yóò dàbí ẹni pé nínú àlá,
    bí ìran ní òru
àti bí ìgbà tí ẹni tí ebi ń pa ń lá àlá pé òun ń jẹun,
    ṣùgbọ́n ó jí, ebi rẹ̀ sì wà pẹ̀lú rẹ̀;
tàbí bí ìgbà tí ẹni tí òǹgbẹ ń gbẹ lá àlá pé òun ń mu omi,
    ṣùgbọ́n nígbà tí ó jí, sì wò ó, ó dákú, òǹgbẹ sì ń gbẹ ọkàn rẹ̀.
Bẹ́ẹ̀ ni yóò sì rí fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè
    tí ń bá òkè Sioni jà.

Ẹ bẹ̀rù kí ẹnu kí ó yà yín,
    ẹ fọ́ ara yín lójú kí ẹ má sì ríran;
ẹ mutí yó kì í ṣe ọtí wáìnì,
    ẹ ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n, ṣùgbọ́n kì í ṣe ti ọtí líle.
10 Olúwa ti mú oorun ìjìká wá sórí i yín:
    ó ti dì yín lójú ẹ̀yin wòlíì;
    ó ti bo orí yín ẹ̀yin aríran.

11 Fún un yín gbogbo ìran yìí kò yàtọ̀ sí àwọn ọ̀rọ̀ tí a fi èdìdì dì sínú ìwé kíká. Bí ẹ bá sì fún ẹni tí ó lè ka ìwé kíká náà, tí ẹ sì sọ fún un pé, “Jọ̀wọ́ ka èyí,” òun yóò dáhùn pé, “Èmi kò lè kà á; a ti dì í ní èdìdì.” 12 Tàbí bí ẹ bá fún ẹni tí kò lè ka ìwé kíká náà tí ẹ sì sọ pé, “Jọ̀wọ́ ka èyí,” òun yóò dáhùn pé, “Èmi kò mọ̀ ọ́n kà.”

13 (D)Olúwa wí pé:

“Àwọn ènìyàn yìí súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi pẹ̀lú ẹnu wọn,
    wọ́n sì bọ̀wọ̀ fún mi pẹ̀lú ètè wọn,
ṣùgbọ́n ọkàn wọn jìnnà sí mi.
    Ìsìn wọn si mi
ni a gbé ka orí òfin tí àwọn
    ọkùnrin kọ́ ni.
14 (E)Nítorí náà lẹ́ẹ̀kan sí i èmi yóò ya
    àwọn ènìyàn yìí lẹ́nu
pẹ̀lú ìyanu lórí ìyanu;
    ọgbọ́n àwọn ọlọ́gbọ́n ni yóò ṣègbé,
    ìmọ̀ àwọn onímọ̀ ni yóò pòórá.”
15 Ègbé ni fún àwọn tí ó lọ sí ọ̀gbun
    láti fi ètò wọn pamọ́ kúrò lójú Olúwa,
tí wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ẹ wọn nínú òkùnkùn
    tí wọ́n sì rò pé,
    “Ta ló rí wa? Ta ni yóò mọ̀?”
16 (F)Ẹ̀yin dojú nǹkan délẹ̀,
    bí ẹni pé wọ́n rò pé amọ̀kòkò dàbí amọ̀!
Ǹjẹ́ ohun tí a ṣe le sọ fún olùṣe pé
    “Òun kọ́ ló ṣe mí”?
Ǹjẹ́ ìkòkò lè sọ nípa amọ̀kòkò pé,
    “kò mọ nǹkan”?

17 Ní àìpẹ́ jọjọ, ǹjẹ́
    a kò ní sọ Lebanoni di pápá ẹlẹ́tù lójú
    àti pápá ẹlẹ́tù lójú yóò dàbí aginjù?
18 (G)Ní ọjọ́ náà adití yóò gbọ́ ọ̀rọ̀ ìwé kíká náà,
    láti inú fìrífìrí àti òkùnkùn
    ni àwọn ojú afọ́jú yóò ríran.
19 Lẹ́ẹ̀kan sí i àwọn onírẹ̀lẹ̀ yóò yọ̀ nínú Olúwa:
    àwọn aláìní yóò yọ̀ nínú Ẹni Mímọ́ ti Israẹli.
20 Aláìláàánú yóò pòórá,
    àwọn tí ń ṣẹlẹ́yà yóò di àwátì,
    gbogbo àwọn tí ó ní ojú ibi ni a ó ké lulẹ̀—
21 àwọn tí wọ́n fi ọ̀rọ̀ kan mú ẹnìkan di ẹlẹ́bi,
    ẹni tí ń dẹkùn mú olùgbèjà ní ilé ẹjọ́
    tí ẹ fi ẹ̀rí èké dun aláìṣẹ̀ ní ìdájọ́.

22 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa, ẹni tí ó ra Abrahamu padà sọ sí ilé Jakọbu:

    “Ojú kì yóò ti Jakọbu mọ́;
    ojú wọn kì yóò sì rẹ̀wẹ̀sì mọ́.
23 Nígbà tí wọ́n bá rí i láàrín àwọn ọmọ wọn,
    àwọn iṣẹ́ ọwọ́ mi,
wọn yóò ya orúkọ mi sí mímọ́,
    wọn yóò tẹ́wọ́gbà mímọ́ Ẹni Mímọ́ Jakọbu
    wọn yóò dìde dúró ní ìbọ̀wọ̀ fún Ọlọ́run Israẹli.
24 Gbogbo àwọn tí ń rìn ségesège ní yóò jèrè ìmọ̀;
    gbogbo àwọn tí ń ṣe àròyé yóò gba ìtọ́sọ́nà.”

30 “Ègbé ni àwọn ọmọ fún orílẹ̀-èdè alágídí,”
    ni Olúwa wí,
“Fún àwọn tí ó gbé ètò jáde tí kì í ṣe tèmi,
    tí wọ́n ń gbìmọ̀ pọ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe nípa Ẹ̀mí mi,
    tí wọ́n ń dá ẹ̀ṣẹ̀ lórí ẹ̀ṣẹ̀;
tí wọ́n lọ sí Ejibiti
    láìṣe fún mi,
tí ó ń wá ìrànlọ́wọ́ lọ́dọ̀ Farao fún ààbò,
    sí òjìji Ejibiti fún ibi ìsádi.
Ṣùgbọ́n ààbò Farao yóò jásí ìtìjú fún un yín,
    òjìji Ejibiti yóò mú àbùkù bá a yín.
Bí àwọn olórí rẹ tilẹ̀ wà ní Ṣoani,
    tí àwọn ikọ̀ wọn sì ti dé sí Hanisi,
gbogbo wọn ni a ó dójútì,
    nítorí àwọn ènìyàn kan tí kò wúlò fún wọn,
tí kò mú ìrànlọ́wọ́ tàbí àǹfààní wá,
    bí kò ṣe àbùkù àti ìdójúti ni.”

Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ sí àwọn ẹranko tí ó wà ní gúúsù:

Láàrín ilẹ̀ ìnira àti ìpọ́njú,
    ti kìnnìún àti abo kìnnìún
ti paramọ́lẹ̀ àti ejò olóró,
    àwọn ikọ̀ náà kó ẹrù àti ọrọ̀
wọn lẹ́yìn àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,
    àwọn ohun ìní wọn ní orí àwọn ìbákasẹ,
    sí orílẹ̀-èdè aláìlérè,
sí Ejibiti tí ìrànlọ́wọ́ rẹ̀
    kò wúlò rárá.
Nítorí náà mo pè é ní
    Rahabu aláìlẹ́ṣẹ̀ nǹkan kan.

Lọ nísinsin yìí, kí o sì kọ ọ́ sí ara wàláà fún wọn,
    tẹ̀ ẹ́ sí ara ìwé kíká,
pé fún àwọn ọjọ́ tí ó ń bọ̀
    kí ó sì lè jẹ́ ẹ̀rí ayérayé.
Àwọn wọ̀nyí jẹ́ ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn
    àti ẹlẹ́tanu ọmọ,
àwọn ọmọ tí wọn kò ṣetán láti tẹ́tí sí
    ìtọ́ni Olúwa.
10 Wọ́n sọ fún àwọn aríran pé,
    “Ẹ má ṣe rí ìran mọ́!”
Àti fún àwọn wòlíì,
    “Ẹ má ṣe fi ìran ohun tí ó tọ́ hàn wá mọ́!
Ẹ sọ ohun tí ó tura fún wa,
    ẹ sàsọtẹ́lẹ̀ ẹ̀tàn.
11 Ẹ fi ọ̀nà yìí sílẹ̀,
    ẹ kúrò ní ọ̀nà yìí
ẹ dẹ́kun à ń dojú ìjà kọ wá
    pẹ̀lú Ẹni Mímọ́ Israẹli!”

12 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Ẹni Mímọ́ Israẹli wí:

“Nítorí pé ẹ ti kọ ọ̀rọ̀ yìí sílẹ̀,
    ẹ gbára lé ìnilára
    kí ẹ sì gbẹ́kẹ̀lé ẹ̀tàn,
13 ẹ̀ṣẹ̀ yìí yóò rí fún ọ
    gẹ́gẹ́ bí ògiri gíga, tí ó sán tí ó sì fì
    tí ó sì wó lójijì, àti ní ìṣẹ́jú kan.
14 Yóò sì fọ́ ọ sí wẹ́wẹ́ bí àpáàdì
    tí a fọ́ pátápátá
àti pé a kò ní rí ẹ̀rún kan nínú àfọ́kù rẹ̀,
    fún mímú èédú kúrò nínú ààrò
    tàbí gbígbọ́n omi jáde kúrò nínú àmù.”

15 Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè, Ẹni Mímọ́ ti Israẹli wí:

“Nínú ìrònúpìwàdà àti ìsinmi ni ìgbàlà rẹ wà,
    ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ àti ìgbẹ́kẹ̀lé ni agbára rẹ wà,
    ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò ní ọ̀kankan nínú wọn.
16 Ẹ̀yin wí pé, ‘bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa yóò sálọ lórí ẹṣin.’
    Nítorí náà ẹ̀yin yóò sá!
Ẹ̀yin wí pé, ‘Àwa yóò gun àwọn ẹṣin tí ó yára lọ.’
    Nítorí náà àwọn tí ń lé e yín yóò yára!
17 Ẹgbẹ̀rún yóò sá
    nípa ìdẹ́rùbà ẹnìkan;
nípa ìdẹ́rùbà ẹni márùn-ún
    gbogbo yín lẹ ó sálọ,
títí a ó fi yín sílẹ̀
    àti gẹ́gẹ́ bí igi àsíá ní orí òkè,
    gẹ́gẹ́ bí àsíá lórí òkè.”

18 Síbẹ̀síbẹ̀ Olúwa sì fẹ́ ṣíjú àánú wò ọ́;
    ó dìde láti ṣàánú fún ọ.
Nítorí Olúwa jẹ́ Ọlọ́run ìdájọ́.
    Ìbùkún ni fún gbogbo àwọn tí ó dúró dè é!

19 Ẹ̀yin ènìyàn Sioni, tí ń gbé ní Jerusalẹmu, ìwọ kì yóò sọkún mọ́. Báwo ni àánú rẹ̀ yóò ti pọ̀ tó nígbà tí ìwọ bá kígbe fún ìrànlọ́wọ́! Bí ó bá ti gbọ́, òun yóò dá ọ lóhùn. 20 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa fún ọ ní àkàrà ìyà àti omi ìpọ́njú, àwọn olùkọ́ rẹ kì yóò fi ara sin mọ́; pẹ̀lú ojú rẹ ni ìwọ ó rí wọn. 21 Bí o bá yí sápá ọ̀tún tàbí apá òsì, etí rẹ yóò máa gbọ́ ohùn kan lẹ́yìn rẹ, wí pé, “Ọ̀nà nìyìí, máa rìn nínú rẹ̀.” 22 Lẹ́yìn náà ni ẹ ó ba àwọn ère yín jẹ́ àwọn tí ẹ fi fàdákà bò àti àwọn ère tí ẹ fi wúrà bò pẹ̀lú, ẹ ó sọ wọ́n nù bí aṣọ tí obìnrin fi ṣe nǹkan oṣù ẹ ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ kúrò níbí!”

23 Òun yóò sì rọ òjò fún un yín sí àwọn irúgbìn tí ẹ gbìn sórí ilẹ̀, oúnjẹ tí yóò ti ilẹ̀ náà wá yóò ní ọ̀rá yóò sì pọ̀. Ní ọjọ́ náà ni àwọn ẹran ọ̀sìn yín yóò máa jẹ koríko ní pápá oko tútù tí ó tẹ́jú. 24 Àwọn màlúù àti àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó ń tú ilẹ̀ yóò jẹ oúnjẹ àdídùn tí a fi àmúga àti ṣọ́bìrì fọ́nkálẹ̀. 25 Ní ọjọ́ tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò sọ ẹ̀mí wọn nù nígbà tí ilé ìṣọ́ yóò wó lulẹ̀, odò omi yóò sàn lórí òkè gíga àti lórí àwọn òkè kékeré. 26 Òṣùpá yóò sì tàn bí oòrùn, àti ìtànṣán oòrùn yóò mọ́lẹ̀ ní ìlọ́po méje, gẹ́gẹ́ bí ìmọ́lẹ̀ odidi ọjọ́ méje, nígbà tí Olúwa yóò di ojú ọgbẹ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ tí yóò sì wo ọgbẹ́ tí ó ti dá sí wọn lára sàn.

27 Kíyèsi i, orúkọ Olúwa ti òkèèrè wá
    pẹ̀lú ìbínú gbígbóná àti kurukuru
èéfín tí ó nípọn;
    ètè rẹ̀ kún fún ìbínú
    ahọ́n rẹ̀ sì jẹ́ iná ajónirun.
28 Èémí rẹ̀ sì dàbí òjò alágbára,
    tí ó rú sókè dé ọ̀run.
Ó jọ àwọn orílẹ̀-èdè nínú kọ̀ǹkọ̀sọ̀;
    ó sì fi sí ìjánu ní àgbọ̀n àwọn ènìyàn
    láti ṣì wọ́n lọ́nà.
29 Ẹ̀yin ó sì kọrin
    gẹ́gẹ́ bí i ti alẹ́ tí ẹ̀ ń ṣe àjọyọ̀ àpéjọ mímọ́,
ọkàn yín yóò yọ̀
    gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí àwọn ènìyàn gòkè lọ pẹ̀lú fèrè
sí orí òkè Olúwa,
    àní sí àpáta Israẹli.
30 Olúwa yóò jẹ́ kí wọn ó gbọ́ ohùn ògo rẹ̀
    yóò sì jẹ́ kí wọ́n rí apá rẹ̀ tí ó ń bọ̀ wálẹ̀
pẹ̀lú ìbínú gbígbóná àti iná ajónirun,
    pẹ̀lú mọ̀nàmọ́ná, àrá àti yìnyín.
31 Ohùn Olúwa yóò fọ́ Asiria túútúú,
    pẹ̀lú ọ̀pá aládé rẹ̀ ni yóò lù wọ́n bolẹ̀.
32 Ẹgba kọ̀ọ̀kan tí Olúwa bá gbé lé wọn
    pẹ̀lú ọ̀pá ìjẹníyà rẹ̀
yóò jẹ́ ti ṣaworo àti ti dùùrù,
    gẹ́gẹ́ bí ó ti ń bá wọn jà lójú ogun
    pẹ̀lú ìkùùkuu láti apá rẹ̀.
33 A ti tọ́jú Tofeti sílẹ̀ tipẹ́tipẹ́,
    a ti tọ́jú rẹ̀ sílẹ̀ fún ọba.
Ojú ààrò rẹ̀ ni a ti gbẹ́ jì tí ó sì fẹ̀,
    pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ iná àti igi ìdáná;
èémí Olúwa,
    gẹ́gẹ́ bí ìṣàn sulfuru ń jó ṣe mú un gbiná.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)

Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.