Print Page Options
Previous Prev Day Next DayNext

Chronological

Read the Bible in the chronological order in which its stories and events occurred.
Duration: 365 days
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Version
Isaiah 59-63

Ẹ̀ṣẹ̀, ìjẹ́wọ́ àti ìràpadà

59 Lódodo ọwọ́ Olúwa kò kúrú láti gbàlà,
    tàbí kí etí rẹ̀ wúwo láti gbọ́.
Ṣùgbọ́n ẹ̀ṣẹ̀ yín ló ti yà yín kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run yín;
    Ẹ̀ṣẹ̀ yín ti fi ojú u rẹ̀ pamọ́ fún un yín
    tó bẹ́ẹ̀ tí òun kò fi le gbọ́.
Nítorí ọwọ́ yín di aláìmọ́ fún ẹ̀jẹ̀,
    àti ìka ọwọ́ yín fún ẹ̀bi.
Ètè yín ń pa irọ́ púpọ̀,
    ahọ́n yín sì ń sọ̀rọ̀ nǹkan ibi.
Kò sí ẹni tí ó béèrè fún ìdájọ́ òdodo;
    kò sí ẹni tí ó ro ẹjọ́ rẹ̀ pẹ̀lú òtítọ́.
Wọ́n gbẹ́kẹ̀lé àwíjàre asán àti ọ̀rọ̀ irọ́;
    wọ́n lóyún ìkà, wọn sì bí wàhálà
Wọn ń pa ẹ̀yin paramọ́lẹ̀
    wọn sì ń ta owú aláǹtakùn.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ẹyin wọn yóò kú,
    àti nígbà tí a pa ọ̀kan, paramọ́lẹ̀ ni ó jáde.
Òwú wọn kò wúlò fún aṣọ rírán;
    wọn kò lè fi aṣọ tí wọ́n hun bo ara wọn.
    Iṣẹ́ wọn jẹ́ ti ibi, ìwà jàǹdùkú sì kún ọwọ́ wọn.
(A)Ẹsẹ̀ wọn yára bọ́ sínú ẹ̀ṣẹ̀;
    wọ́n yára láti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀.
Èrò wọn sì jẹ́ èrò ibi;
    ìparun àti ìdahoro ni ó wà ní ṣíṣe ààmì ọ̀nà wọn.
Ọ̀nà àlàáfíà èyí ni wọn kò mọ̀;
    kò sí òdodo ní ojú ọ̀nà wọn
wọ́n ti sọ wọ́n dì ọ̀nà kọ́rọkọ̀rọ,
    kò sí ẹni tí ó tọ ọ̀nà yìí tí yóò rí àlàáfíà.

Nítorí èyí ni ẹ̀tọ́ fi jìnnà sí wa,
    àti tí òdodo kò fi tẹ̀ wá lọ́wọ́.
A ń wá ìmọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n gbogbo rẹ̀ jẹ́ òkùnkùn;
    ìmọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n à ń rìn nínú òjìji.
10 Gẹ́gẹ́ bí afọ́jú à ń táràrà lọ lẹ́gbẹ̀ẹ́ ògiri
    tí a ń wá ọ̀nà wa gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí kò ní ojú.
Ní ọ̀sán gangan ni à ń kọsẹ̀ bí ẹni pé alẹ́ ni;
    láàrín alágbára àwa dàbí òkú.
11 Gbogbo wa là ń ké bí i beari;
    àwa pohùnréré ẹkún bí àdàbà
A ń wá ìdájọ́ òdodo ṣùgbọ́n kò sí; à ń wọ́nà
    fún ìtúsílẹ̀, ṣùgbọ́n ó jìnnà réré.

12 Nítorí àwọn àṣìṣe wa pọ̀ níwájú rẹ,
    àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa sì ń jẹ́rìí takò wá.
Àwọn àìṣedéédéé wa sì wà pẹ̀lú wa,
    àwa pẹ̀lú sì mọ àìṣedéédéé wa,
13 ọ̀tẹ̀ àti àrékérekè wa sí Olúwa,
    kíkọ ẹ̀yìn wa sí Ọlọ́run,
dídá yánpọnyánrin àti ìnilára sílẹ̀,
    pípààrọ̀ tí ọkàn wa ti gbèrò síta.
14 Nítorí èyí ni a ṣe lé ìdájọ́ òdodo sẹ́yìn,
    àti ti òdodo dúró lókèèrè;
òtítọ́ ti ṣubú ní òpópó ọ̀nà,
    òdodo kò sì le è wọlé.
15 A kò rí òtítọ́ mọ́,
    àti ẹni tí ó bá sá fun ibi tì di ìjẹ.

Olúwa wò ó ọkàn rẹ̀ sì bàjẹ́
    pé kò sí ìdájọ́ òdodo.
16 Òun rí i pé kò sí ẹnìkan,
    àyà fò ó pé kò sí ẹnìkan láti ṣèrànwọ́;
nítorí apá òun tìkára rẹ̀ ló ṣiṣẹ́ ìgbàlà fún ara rẹ̀,
    àti òdodo òun tìkára rẹ̀ ló gbé e ró.
17 (B)Ó gbé òdodo wọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbàyà rẹ̀,
    àti àṣíborí ìgbàlà ní orí rẹ̀;
ó gbé ẹ̀wù ẹ̀san wọ̀
    ó sì yí ara rẹ̀ ní ìtara bí ẹ̀wù.
18 Gẹ́gẹ́ bí ohun tí wọ́n ti ṣe,
    bẹ́ẹ̀ ni yóò san án
ìbínú fún àwọn ọ̀tá rẹ̀
    àti ẹ̀san fún àwọn ọ̀tá rẹ̀;
    òun yóò san án fún àwọn erékùṣù ẹ̀tọ́ wọn.
19 (C)Láti ìwọ̀-oòrùn, àwọn ènìyàn yóò bẹ̀rù orúkọ Olúwa,
    àti láti ìlà-oòrùn, wọn yóò bọ̀wọ̀ fún ògo rẹ̀.
Nítorí òun yóò wá gẹ́gẹ́ bí i rírú omi
    èyí tí èémí Olúwa ń tì lọ.

20 (D)“Olùdáǹdè yóò wá sí Sioni,
    sí àwọn tí ó wà ní Jakọbu tí ó
    ronúpìwàdà ẹ̀ṣẹ̀ wọn,” ni Olúwa wí.

21 “Àti fún èmi, májẹ̀mú mi pẹ̀lú wọn nìyìí,” ni Olúwa wí, “Ẹ̀mí mi, tí ó wà nínú yín, àti ọ̀rọ̀ mi tí mo ti fi sí ẹnu yín, kì yóò kúrò lẹ́nu yín, tàbí lẹ́nu àwọn ọmọ yín, tàbí láti ẹnu àwọn ìrandíran wọn láti àkókò yìí lọ àti títí láéláé” ni Olúwa wí.

Ògo Sioni

60 “Dìde, tànmọ́lẹ̀, nítorí ìmọ́lẹ̀ rẹ ti dé,
    ògo Olúwa sì ràdàbò ọ́.
Kíyèsi i, òkùnkùn bo ilẹ̀ ayé
    òkùnkùn biribiri sì wà lórí àwọn ènìyàn,
ṣùgbọ́n Olúwa ràn bò ọ́
    ògo rẹ̀ sì farahàn lórí i rẹ.
Àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá sí ìmọ́lẹ̀ rẹ,
    àti àwọn ọba sí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀ rẹ.

“Gbé ojú rẹ sókè, kí o sì wò:
    Gbogbo wọn ṣa ara jọ pọ̀, wọ́n sì wá sọ́dọ̀ rẹ;
àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin yóò wá láti ọ̀nà jíjìn,
    àwọn ọmọ rẹ obìnrin ni a ó tọ́jú ní ẹ̀gbẹ́ rẹ.
Nígbà náà ni ìwọ yóò wò tí ojú rẹ yóò máa dán,
    ọkàn rẹ yó fò, yó sì kún fún ayọ̀;
ọrọ̀ inú Òkun ni a ó kò wá sọ́dọ̀ rẹ,
    sí ọ̀dọ̀ rẹ ni ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá.
(E)Ọ̀wọ́ ìbákasẹ yóò bo gbogbo ilẹ̀ rẹ,
    àwọn ọ̀dọ́ ìbákasẹ Midiani àti Efani.
Àti gbogbo wọn láti Ṣeba yóò wá,
    wọn yóò mú wúrà àti tùràrí lọ́wọ́
    tí wọn yóò sì máa kéde ìyìn Olúwa.
Gbogbo agbo ẹran Kedari ni a ó kójọ sọ́dọ̀ rẹ,
    àwọn àgbò ti Nebaioti yóò sìn ọ́;
wọn yóò jẹ́ ọrẹ ìtẹ́wọ́gbà lórí i pẹpẹ mi,
    bẹ́ẹ̀ ni n ó sì ṣe tẹmpili ògo mi lọ́ṣọ̀ọ́.

“Ta ni àwọn wọ̀nyí tí ń fò lọ bí i kurukuru,
    gẹ́gẹ́ bí àwọn àdàbà sí ìtẹ́ wọn?
Lóòtítọ́ àwọn erékùṣù bojú wò mí;
    ní ìṣíwájú ni àwọn ọkọ̀ ojú omi Tarṣiṣi;
mú àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ wá láti ọ̀nà jíjìn,
    pẹ̀lú fàdákà àti wúrà wọn,
fún ti ọlá Olúwa Ọlọ́run rẹ,
    Ẹni Mímọ́ Israẹli,
    nítorí òun ti fi ohun dídára ṣe ó lọ́ṣọ̀ọ́.

10 “Àwọn àjèjì yóò tún ògiri rẹ mọ
    àwọn ọba wọn yóò sì sìn ọ́.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ní ìbínú ni mo lù ọ́,
    ní àánú èmi yóò ṣe inú rere sí ọ.
11 (F)Gbogbo ẹnu-bodè rẹ ni yóò wà ní ṣíṣí sílẹ̀,
    a kì yóò tì wọ́n ní ọ̀sán àti ní òru,
tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ọkùnrin yóò le è kó
    ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè wá
tí àwọn ọba wọn yóò ṣáájú ní
    ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ ìṣẹ́gun.
12 Nítorí pé orílẹ̀-èdè tàbí ilẹ̀ ọba tí kì yóò sìn ọ́ ni yóò parun;
    pátápátá ni yóò sì dahoro.

13 “Ògo Lebanoni yóò wá sí ọ̀dọ̀ rẹ,
    igi junifa, firi àti sípírẹ́ṣì papọ̀,
láti bu ọlá fún ilé ìsìn mi;
    àti pé èmi yóò sì ṣe ibi ẹsẹ̀ mi lógo.
14 (G)Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àwọn apọ́nilójú rẹ yóò
    wá foríbalẹ̀ fún ọ;
gbogbo àwọn tí ó ti kẹ́gàn rẹ ni wọn yóò tẹríba níwájú rẹ
    wọn yóò sì pè ọ́ ní ìlú Olúwa,
    Sioni ti Ẹni Mímọ́ Israẹli.

15 “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a ti kórìíra rẹ, a sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀,
    láìsí ẹnìkan tí ó ń gba ọ̀dọ̀ rẹ kọjá,
Èmi yóò ṣe ọ́ ní ìṣògo ayérayé
    àti ayọ̀ àtìrandíran.
16 Ìwọ yóò mu wàrà gbogbo orílẹ̀-èdè
    a ó sì fun ọ́ ni ọmú àwọn ọba.
Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé Èmi Olúwa,
    èmi ni Olùgbàlà rẹ,
    Olùdáǹdè rẹ, Alágbára ti Jakọbu.
17 Dípò idẹ, èmi ó mú wúrà wá fún ọ,
    dípò fàdákà èmi ó mú irin wá. Dípò igi yóò mú idẹ wá fún ọ,
àti irin dípò òkúta.
    Èmi yóò fi àlàáfíà ṣe àwọn ìjòyè rẹ
    àti òdodo gẹ́gẹ́ bí alákòóso rẹ.
18 A kì yóò gbọ́ nípa rògbòdìyàn ní ilẹ̀ rẹ mọ́,
    tàbí ìdahoro àti ìparun nínú agbègbè rẹ,
ṣùgbọ́n ìwọ yóò pe ògiri rẹ ní ìgbàlà
    àti àwọn ẹnu-bodè rẹ ní ìyìn.
19 Òòrùn kì yóò sì jẹ́ ìmọ́lẹ̀ rẹ ní ọ̀sán mọ́,
    tàbí kí ìtànṣán òṣùpá tún ràn sí ọ mọ́,
nítorí Olúwa ni yóò jẹ́ ìmọ́lẹ̀ rẹ ayérayé,
    àti Ọlọ́run rẹ yóò jẹ́ ògo rẹ.
20 Òòrùn rẹ kì yóò sì wọ̀ mọ́,
    àti òṣùpá rẹ kì yóò sì wọ òòkùn mọ́;
Olúwa ni yóò jẹ́ ìmọ́lẹ̀ ayérayé rẹ,
    àti àwọn ọjọ́ arò rẹ yóò sì dópin.
21 Lẹ́yìn náà ni gbogbo àwọn ènìyàn rẹ yóò di òdodo
    àwọn ni yóò sì jogún ilẹ̀ náà títí ayé.
Àwọn ni irúgbìn tí mo ti gbìn,
    iṣẹ́ ọwọ́ mi,
    láti fi ọláńlá mi hàn.
22 Èyí tí ó kéré jù nínú yín yóò di ẹgbẹ̀rún kan,
    èyí tí ó kéré yóò di orílẹ̀-èdè ńlá.
Èmi ni Olúwa;
    ní àkókò rẹ̀ Èmi yóò ṣe èyí kánkán.”

Ọdún ojúrere Olúwa

61 (H)Ẹ̀mí Olúwa Olódùmarè wà lára mi
    nítorí Olúwa ti fi ààmì òróró yàn mí
láti wàásù ìhìnrere fún àwọn tálákà.
    Ó ti rán mi láti ṣe àwòtán oníròbìnújẹ́
láti kéde ìdásílẹ̀ fún àwọn ìgbèkùn
    àti ìtúsílẹ̀ kúrò nínú òkùnkùn fún àwọn ẹlẹ́wọ̀n,
Láti kéde ọdún ojúrere Olúwa
    àti ọjọ́ ẹ̀san ti Ọlọ́run wa,
    láti tu àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ nínú,
àti láti pèsè fún àwọn tí inú wọn bàjẹ́ ní Sioni
    láti dé wọn ládé ẹwà dípò eérú,
òróró ayọ̀ dípò ọ̀fọ̀,
    àti aṣọ ìyìn dípò ìpòrúru ọkàn.
A ó sì pè wọ́n ní igi óákù òdodo,
    irúgbìn Olúwa
    láti fi ọláńlá rẹ̀ hàn.

Wọn yóò tún àwọn ahoro àtijọ́ kọ́
    wọn yóò sì mú àwọn ibi ìparun àtijọ́-tijọ́ náà bọ̀ sípò;
wọn yóò jí àwọn ahoro ìlú náà padà
    tí a ti parun láti ìrandíran sẹ́yìn.
Àwọn àjèjì ni yóò máa da ọ̀wọ́ ẹran rẹ;
    àwọn àlejò yóò sì ṣiṣẹ́ nínú oko àti ọgbà àjàrà rẹ.
A ó sì máa pè yín ní àlùfáà Olúwa,
    a ó pè yín ní ìránṣẹ́ Ọlọ́run wa.
Ẹ ó máa jẹ nínú ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè
    àti nínú ọrọ̀ wọn ni ẹ̀yin yóò máa ṣògo.

Dípò àbùkù wọn
    àwọn ènìyàn mi yóò gba ìlọ́po méjì,
àti dípò àbùkù wọn
    wọn yóò yọ̀ nínú ìní wọn;
bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò sì jogún ìlọ́po méjì ní ilẹ̀ wọn,
    ayọ̀ ayérayé yóò sì jẹ́ tiwọn.

“Nítorí Èmi, Olúwa fẹ́ràn ìdájọ́ òdodo;
    mo kórìíra olè jíjà àti ẹ̀ṣẹ̀
Ní òtítọ́ mi èmi yóò sẹ̀san fún wọn
    èmi yóò sì dá májẹ̀mú ayérayé pẹ̀lú wọn.
A ó mọ ìrandíran wọn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè
    àti àwọn ìran wọn láàrín àwọn ènìyàn
Gbogbo àwọn tí ó bá rí wọn yóò mọ̀ pé
    wọ́n jẹ́ àwọn ènìyàn tí Olúwa ti bùkún.”

10 Èmi yọ̀ gidigidi nínú Olúwa;
    ọkàn mi yọ̀ nínú Ọlọ́run mi.
Nítorí ó ti wọ̀ mí ní aṣọ ìgbàlà
    ó sì ṣe mí lọ́ṣọ̀ọ́ nínú aṣọ òdodo;
gẹ́gẹ́ bí ọkọ ìyàwó ti ṣe orí rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́ bí àlùfáà,
    àti bí ìyàwó ṣe ń ṣe ara rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́ pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́.
11 Gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ti í mú irúgbìn jáde
    àti bí ọgbà ṣe ń mú irúgbìn dàgbà,
Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè yóò ṣe mú òdodo àti ìyìn
    kí ó ru sókè níwájú gbogbo orílẹ̀-èdè.

Orúkọ Sioni tuntun

62 Nítorí Sioni èmi kì yóò dákẹ́,
    nítorí i Jerusalẹmu èmi kì yóò sinmi ẹnu,
títí tí òdodo rẹ̀ yóò fi tàn bí òwúrọ̀,
    àti ìgbàlà rẹ̀ bí i fìtílà tí ń jó geere.
(I)Àwọn orílẹ̀-èdè yóò rí òdodo rẹ,
    àti gbogbo ọba ògo rẹ
a ó sì máa pè ọ́ ní orúkọ mìíràn
    èyí tí ẹnu Olúwa yóò fi fún un.
Ìwọ yóò sì jẹ́ adé dídán ní ọwọ́ Olúwa,
    adé ọba ní ọwọ́ Ọlọ́run rẹ.
Wọn kì yóò pè ọ́ ní ìkọ̀sílẹ̀ mọ́
    tàbí kí wọ́n pe ilẹ̀ rẹ ní ahoro.
Ṣùgbọ́n a ó máa pè ọ́ ní Hẹfsiba,
    àti ilẹ̀ rẹ ní Beula;
nítorí Olúwa yóò yọ́nú sí ọ
    àti ilẹ̀ rẹ ni a ó gbé níyàwó.
Gẹ́gẹ́ bí ọ̀dọ́mọkùnrin tí í gbé ọ̀dọ́mọbìnrin níyàwó
    bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọkùnrin rẹ yóò gbé ọ níyàwó
Gẹ́gẹ́ bí ọkọ ìyàwó ṣe é yọ̀ lórí ìyàwó rẹ̀,
    bẹ́ẹ̀ ni Ọlọ́run rẹ yóò yọ̀ lórí rẹ.

Èmi ti fi olùṣọ́ ránṣẹ́ sórí odi rẹ ìwọ Jerusalẹmu;
    wọn kì yóò lè dákẹ́ tọ̀sán tòru.
Ẹ̀yin tí ń ké pe Olúwa,
    ẹ má ṣe fúnrayín ní ìsinmi,
àti kí ẹ má ṣe fún òun pẹ̀lú ní ìsinmi
    títí tí yóò fi fi ìdí Jerusalẹmu múlẹ̀
    tí yóò sì fi ṣe ìyìn orí ilẹ̀ ayé.

Olúwa ti búra pẹ̀lú ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀
    àti nípa agbára apá rẹ:
“Èmi kì yóò jẹ́ kí ìyẹ̀fun rẹ
    di oúnjẹ fún ọ̀tá rẹ
bẹ́ẹ̀ ni àwọn àjèjì kì yóò mu wáìnì
    tuntun rẹ mọ́
    èyí tí ìwọ ti ṣe làálàá fún;
ṣùgbọ́n àwọn tí ó bá kóórè rẹ̀ ni yóò jẹ ẹ́,
    tí wọn ó sì yin Olúwa,
àti àwọn tí wọ́n bá kó àjàrà jọ ni wọn ó mú un,
    nínú àgbàlá ilé mímọ́ mi.”

10 Ẹ kọjá, ẹ kọjá ní ẹnu ibodè náà!
    Ẹ tún ọ̀nà ṣe fún àwọn ènìyàn.
Ẹ mọ ọ́n sókè, ṣe ojú ọ̀nà òpópó!
    Ẹ ṣa òkúta kúrò
    Ẹ gbé àsíá sókè fún àwọn orílẹ̀-èdè.

11 Olúwa ti ṣe ìkéde
    títí dé òpin ilẹ̀ ayé:
“Ẹ sọ fún ọmọbìnrin Sioni pé,
    ‘kíyèsi i, Olùgbàlà rẹ ń bọ̀!
Kíyèsi i, èrè ń bẹ pẹ̀lú rẹ̀,
    àti ẹ̀san rẹ̀ pẹ̀lú n tẹ̀lé e lẹ́yìn.’ ”
12 A ó sì pè wọ́n ní Ènìyàn Mímọ́,
    ẹni ìràpadà Olúwa;
a ó sì máa pè ọ́ ní ìwákiri,
    Ìlú tí a kì yóò kọ̀sílẹ̀.

Ọjọ́ ẹ̀san àti ìràpadà Ọlọ́run

63 (J)Ta nì eléyìí tí ó Edomu wá,
    ti òun ti aṣọ àrẹpọ́n láti Bosra wá?
Ta nì eléyìí, tí ó ní ògo nínú aṣọ rẹ̀,
    tí ó ń yan bọ̀ wá nínú ọláńlá agbára rẹ̀?

    “Èmi ni ẹni tí ó ń sọ̀rọ̀ nínú òdodo
    tí ó ní ipa láti gbàlà.”

Èéṣe tí aṣọ yín fi pupa
    gẹ́gẹ́ bí i tàwọn tí ń ṣiṣẹ́ ní ìfúntí?

(K)“Èmi nìkan ti dá tẹ ìfúntí wáìnì;
    láti àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹnikẹ́ni kò sì wà pẹ̀lú mi.
Mo tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ ní ìbínú mi
    mo sì tẹ̀ wọ́n rẹ́ ní ìrunú mi
ẹ̀jẹ̀ wọn sì fọ́n sí aṣọ mi,
    mo sì da àbàwọ́n sí gbogbo aṣọ mi.
Nítorí ọjọ́ ẹ̀san wà ní ọkàn mi
    àti pé ọdún ìràpadà mi ti dé
Mo wò, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan láti ṣe ìrànwọ́.
    Àyà fò mí pé ẹnikẹ́ni kò ṣèrànwọ́;
nítorí náà apá mi ni ó ṣiṣẹ́ ìgbàlà fún mi
    àti ìrunú mi ni ó gbé mi ró.
Mo tẹ orílẹ̀-èdè mọ́lẹ̀ nínú ìbínú mi;
    nínú ìrunú mi mo jẹ́ kí wọ́n mu
    mo sì da ẹ̀jẹ̀ wọn sílẹ̀ lórí erùpẹ̀.”

Ìyìn àti àdúrà

Èmi yóò sọ nípa àánú Olúwa
    ìṣe rẹ gbogbo tí ó yẹ kí a yìn ín fún,
gẹ́gẹ́ bí ohun tí Olúwa ti ṣe fún wa
    bẹ́ẹ̀ ni, ohun rere gbogbo tí ó ti ṣe
fún ilé Israẹli
    gẹ́gẹ́ bí àánú àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ oore rẹ̀.
Ó wí pé, “Lóòtítọ́ ènìyàn mi ni wọ́n,
    àwọn ọmọ tí kì yóò jẹ́ òpùrọ́ fún mi”;
    bẹ́ẹ̀ ni, ó sì di Olùgbàlà wọn.
Nínú gbogbo ìpọ́njú wọn, inú òun pẹ̀lú bàjẹ́
    àti angẹli tí ó wà níwájú rẹ̀ gbà wọ́n là.
Nínú ìfẹ́ àti àánú rẹ̀, ó rà wọ́n padà;
    ó gbé wọn sókè ó sì pọ̀n wọ́n
    ní gbogbo ọjọ́ ìgbà n nì.
10 Síbẹ̀síbẹ̀ wọ́n ṣọ̀tẹ̀
    wọ́n sì ba Ẹ̀mí Mímọ́ rẹ̀ nínú jẹ́.
Bẹ́ẹ̀ ni ó yípadà ó sì di ọ̀tá wọn
    òun tìkára rẹ̀ sì bá wọn jà.

11 (L)Lẹ́yìn náà ni àwọn ènìyàn rẹ̀ rántí ọjọ́ ìgbà n nì,
    àwọn ọjọ́ Mose àti àwọn ènìyàn rẹ̀
níbo ni ẹni náà wà tí ó mú wọn la Òkun já,
    pẹ̀lú olùṣọ́-àgùntàn agbo ẹran rẹ̀?
Níbo ni ẹni náà wà tí ó rán
    Ẹ̀mí Mímọ́ rẹ̀ sáàrín wọn,
12 ta ni ó rán apá ògo ti agbára rẹ̀
    láti wà ní apá ọ̀tún Mose,
ta ni ó pín omi ní yà níwájú wọn,
    láti gba òkìkí ayérayé fún ara rẹ̀,
13 ta ni ó síwájú wọn la àwọn ọ̀gbun nì já?
    Gẹ́gẹ́ bí ẹṣin ni gbangba ìlú wọn tí kò sì kọsẹ̀;
14 gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran tí ó lọ sí pápá oko,
    a fún wọn ní ìsinmi láti ọwọ́ Ẹ̀mí Olúwa.
Báyìí ni ẹ ṣe tọ́ àwọn ènìyàn yín
    láti fún ara yín ní orúkọ kan tí ó lógo.

15 Bojú wolẹ̀ láti ọ̀run kí o sì rí i
    láti ìtẹ́ ògo rẹ, mímọ́ àti ológo.
Níbo ni ìtara àti agbára rẹ wà?
    Ìwà jẹ́ẹ́jẹ́ rẹ àti àánú rẹ ni a
    ti mú kúrò níwájú wa.
16 Ṣùgbọ́n ìwọ ni baba wa,
    bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Abrahamu kò mọ̀ wá
tàbí Israẹli mọ ẹni tí à á ṣe;
    ìwọ, Olúwa ni Baba wa,
    Olùràpadà wa láti ìgbà n nì ni orúkọ rẹ.
17 Èéṣe Olúwa tí o fi jẹ́ kí a ṣáko kúrò ní ojú ọ̀nà rẹ
    tí o sì ṣé àyà wa le tó bẹ́ẹ̀ tí àwa kò fi bọ̀wọ̀ fún ọ?
Padà nítorí àwọn ìránṣẹ́ rẹ,
    àwọn ẹ̀yà tí ṣe ogún ìní rẹ.
18 Fún ìgbà díẹ̀ ni àwọn ènìyàn rẹ fi gba ibi mímọ́ rẹ,
    ṣùgbọ́n nísinsin yìí àwọn ọ̀tá wa ti tẹ ibi mímọ́ rẹ mọ́lẹ̀.
19 Àwa jẹ́ tìrẹ láti ìgbà n nì;
    ṣùgbọ́n ìwọ kò tí ì jẹ ọba lé wọn lórí,
    a kò sì tí ì pè wọ́n mọ́ orúkọ rẹ.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)

Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.