Print Page Options
Previous Prev Day Next DayNext

Chronological

Read the Bible in the chronological order in which its stories and events occurred.
Duration: 365 days
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Version
Isaiah 40-43

Ìtùnú fún àwọn ènìyàn Ọlọ́run

40 Ẹ tù ú nínú, ẹ tu ènìyàn mi nínú,
    ni Ọlọ́run yín wí.
Sọ̀rọ̀ pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ fún Jerusalẹmu
    kí o sì kéde fún un
pé iṣẹ́ àṣekára rẹ̀ ti parí,
    pé à ti san gbèsè ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀,
pé ó ti rí i gbà láti ọwọ́ Olúwa
    ìlọ́po méjì fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.

(A)Ohùn ẹni tí ń kígbe ní ijù:
    “Ẹ tún ọ̀nà Olúwa ṣe,
    ṣe òpópó tí ó tọ́ ní aginjù fún Ọlọ́run wa.
(B)Gbogbo Àfonífojì ni a ó gbé sókè,
    gbogbo òkè ńlá àti òkè kékeré ni yóò di pẹ̀tẹ́lẹ̀;
wíwọ́ ni a ó sọ di títọ́ àti
    ọ̀nà pálapàla ni a óò sọ di títẹ́jú pẹrẹsẹ,
Ògo Olúwa yóò sì di mí mọ̀
    gbogbo ènìyàn lápapọ̀ ni yóò sì rí i.
    Nítorí ẹnu Olúwa ni ó ti sọ ọ́.”

(C)Ohùn kan wí pé, “Kígbe sókè.”
    Èmi sì sọ pé, “Igbe kí ni èmi ó ké?”

“Gbogbo ènìyàn dàbí i koríko,
    àti gbogbo ògo wọn dàbí ìtànná igbó.
Koríko ń rọ ìtànná sì ń rẹ̀,
    nítorí èémí Olúwa ń fẹ́ lù wọ́n.
    Nítòótọ́ koríko ni àwọn ènìyàn.
Koríko ń rọ ìtànná sì ń rẹ̀,
    ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Ọlọ́run wa dúró títí láé.”

(D)Ìwọ tí o mú ìyìn ayọ̀ wá sí Sioni,
    lọ sí orí òkè gíga.
Ìwọ tí ó mú ìyìn ayọ̀ wá sí Jerusalẹmu,
    gbé ohùn rẹ sókè pẹ̀lú ariwo,
gbé e sókè, má ṣe bẹ̀rù;
    sọ fún àwọn ìlú u Juda,
    “Ọlọ́run rẹ nìyìí!”
10 (E)Wò ó, Olúwa Olódùmarè náà ń bọ̀ wá pẹ̀lú agbára,
    apá rẹ̀ sì ń jẹ ọba fún un.
Wò ó, èrè rẹ̀ sì wà pẹ̀lú rẹ̀,
    àti ìdápadà rẹ̀ tí ń bá a bọ̀ wá.
11 Ó ń tọ́ àwọn agbo rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́-àgùntàn:
    Ó kó àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn ní apá rẹ̀.
Ó sì gbé wọn súnmọ́ oókan àyà rẹ̀;
    ó sì fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ darí àwọn tí ó ní.

12 Ta ni ó tiwọn omi nínú kòtò ọwọ́ rẹ̀,
    tàbí pẹ̀lú ìbú ọwọ́ rẹ̀
tí ó wọn àwọn ọ̀run?
    Ta ni ó ti kó erùpẹ̀ ilẹ̀ ayé jọ nínú apẹ̀rẹ̀,
tàbí kí ó wọn àwọn òkè ńlá lórí ìwọ̀n
    àti òkè kéékèèkéé nínú òṣùwọ̀n?
13 (F)Ta ni ó ti mọ ọkàn Olúwa,
    tàbí tí ó ti tọ́ ọ ṣọ́nà gẹ́gẹ́ bí olùdámọ̀ràn rẹ̀?
14 Ta ni Olúwa ké sí kí ó là á lọ́yẹ
    àti ta ni ó kọ́ òun ní ọ̀nà tí ó tọ́?
Ta ni ẹni náà tí ó kọ́ ọ ní ọgbọ́n
    tàbí tí ó fi ipa ọ̀nà òye hàn án?

15 Nítòótọ́ àwọn orílẹ̀-èdè dàbí i ẹ̀kún omi
    nínú garawa;
a kà wọ́n sí gẹ́gẹ́ bí eruku lórí ìwọ̀n;
    ó wọn àwọn erékùṣù àfi bí eruku múnúmúnú ni wọ́n.
16 Lebanoni kò tó fún pẹpẹ iná,
    tàbí kí àwọn ẹranko rẹ̀ kí ó tó fún ẹbọ sísun.
17 Níwájú rẹ̀ ni gbogbo orílẹ̀-èdè dàbí ohun tí kò sí;
    gbogbo wọn ló kà sí ohun tí kò wúlò
    tí kò tó ohun tí kò sí.

18 Ta ni nígbà náà tí ìwọ yóò fi Ọlọ́run wé?
    Ère wo ni ìwọ yóò fi ṣe àkàwé rẹ̀?
19 Ní ti ère, oníṣọ̀nà ni ó dà á,
    ti alágbẹ̀dẹ wúrà sì fi wúrà bò ó
    tí a sì ṣe ẹ̀wọ̀n ọ̀nà sílífà fún un.
20 Ọkùnrin kan tí ó tálákà jù kí ó lè mú
    irú ọrẹ bẹ́ẹ̀ wá,
wá igi tí kò le è rà.
    Ó wá oníṣọ̀nà tí ó
    láti ṣe àgbékalẹ̀ ère tí kì yóò le è ṣubú.

21 Ǹjẹ́ o kò tí ì mọ̀
    ìwọ kò tí ì gbọ́?
A kò tí ì sọ fún ọ láti ìbẹ̀rẹ̀ wá?
    Ìwọ kò tí ì mọ láti ìgbà ìpìlẹ̀ ayé?
22 Òun jókòó lórí ìtẹ́ ní òkè òbírí ilẹ̀ ayé,
    àwọn ènìyàn rẹ̀ sì dàbí i láńtata.
Ó ta àwọn ọ̀run bí ìbòrí ìgúnwà,
    ó sì nà wọ́n jáde gẹ́gẹ́ bí àgọ́ láti gbé.
23 Ó sọ àwọn ọmọ ọba di asán
    àti àwọn aláṣẹ ayé yìí ni ó ti sọ dòfo.
24 Gẹ́rẹ́ tí a ti gbìn wọ́n,
    kété tí a gbìn wọ́n,
kété tí wọ́n fi gbòǹgbò múlẹ̀,
    bẹ́ẹ̀ ni ó fẹ́ atẹ́gùn lù wọ́n gbogbo wọn sì gbẹ,
    bẹ́ ni ìjì líle sì gbá wọn lọ gẹ́gẹ́ bí ìyàngbò.

25 “Ta ni ẹ ó fi mi wé?
    Tàbí ta ni ó bá mi dọ́gba?” ni Ẹni Mímọ́ wí.
26 Gbé ojú rẹ sókè kí o sì wo àwọn ọ̀run:
    Ta ni ó dá àwọn wọ̀nyí?
Ẹni tí ó mú àkójọpọ̀ àwọn ìràwọ̀ jáde wá ní ọ̀kọ̀ọ̀kan
    tí ó sì pè wọ́n ní orúkọ lọ́kọ̀ọ̀kan.
Nítorí agbára ńlá àti ipá rẹ̀,
    ọ̀kan ṣoṣo nínú wọn kò sọnù.

27 Èéṣe tí o fi sọ, ìwọ Jakọbu
    àti tí o ṣàròyé, ìwọ Israẹli;
“Ọ̀nà mi pamọ́ níwájú Olúwa;
    ìṣe mi ni a kò kọbi ara sí
    láti ọwọ́ Ọlọ́run mi”?
28 Ìwọ kò tí ì mọ̀?
    Ìwọ kò tí ì gbọ́?
Olúwa òun ni Ọlọ́run ayérayé,
    Ẹlẹ́dàá gbogbo ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé.
Agara kì yóò da bẹ́ẹ̀ ni kò ní ṣàárẹ̀,
    àti òye rẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kò le ṣe òdínwọ̀n rẹ̀.
29 Ó ń fi agbára fún àwọn aláàárẹ̀
    ó sì fi kún agbára àwọn tí agara dá.
30 Àní, ó ń rẹ̀ wọ́n àwọn ọ̀dọ́, wọ́n ń rẹ̀wẹ̀sì,
    àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì ń kọsẹ̀ wọ́n ṣubú;
31 ṣùgbọ́n àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa
    yóò sọ agbára wọn di ọ̀tun.
Wọn yóò fìyẹ́ fò lókè bí idì;
    wọn yóò sáré àárẹ̀ kò ní mú wọn,
    wọn yóò rìn òòyì kò ní kọ́ wọn.

Olùrànlọ́wọ́ fún Israẹli

41 “Ẹ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú mi ẹ̀yin erékùṣù!
    Jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè tún agbára wọn ṣe!
Jẹ́ kí wọn wá síwájú kí wọn sọ̀rọ̀:
    Jẹ́ kí a pàdé pọ̀ ní ibi ìdájọ́.

“Ta ni ó ti ru ẹnìkan sókè láti ìlà-oòrùn wá,
    tí ó pè é ní olódodo sí iṣẹ́ tirẹ̀?
Ó gbé àwọn orílẹ̀-èdè lé e lọ́wọ́
    ó sì ṣẹ́gun àwọn ọba níwájú rẹ̀.
Ó sọ wọ́n di erùpẹ̀ pẹ̀lú idà rẹ̀,
    láti kù ú ní ìyàngbò pẹ̀lú ọrun rẹ̀.
Ó ń lépa wọn ó sì ń kọjá ní àlàáfíà,
    ní ojú ọ̀nà tí ẹsẹ̀ rẹ̀ kò rìn rí.
Ta ni ó ti ṣe èyí tí ó sì ti jẹ́ kí ó wáyé,
    tí ó ti pe ìran-ìran láti àtètèkọ́ṣe?
Èmi Olúwa pẹ̀lú ẹni kìn-ín-ní wọn
    àti ẹni tí ó gbẹ̀yìn, Èmi náà ni.”

Àwọn erékùṣù ti rí i wọ́n bẹ̀rù;
    ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé wárìrì.
    Wọ́n súnmọ́ tòsí wọ́n sì wá síwájú
Èkínní ran èkejì lọ́wọ́
    ó sì sọ fún arákùnrin rẹ̀ pé
    “Jẹ́ alágbára!”
Oníṣọ̀nà gba alágbẹ̀dẹ wúrà níyànjú,
    àti ẹni tí ó fi òòlù dán
mú òun lọ́kàn le, àní ẹni tí ó ń lu owú.
Ó sọ nípa àjópọ̀ náà pé, “Ó dára.”
    Ó fi ìṣó kan ère náà mọ́lẹ̀ kí ó má ba à wó lulẹ̀.

(G)(H) “Ṣùgbọ́n ìwọ, ìwọ Israẹli, ìránṣẹ́ mi,
    Jakọbu, ẹni tí mo ti yàn,
    ẹ̀yin ìran Abrahamu, ọ̀rẹ́ mi,
mo mú ọ láti ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé,
    láti kọ̀rọ̀ rẹ̀ tí ó jìnnà jùlọ ni mo ti pè ọ́.
Èmi wí pé, ‘Ìwọ ni ìránṣẹ́ mi;’
    Èmi ti yàn ọ́ bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì tí ì kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
10 (I)Nítorí náà má bẹ̀rù, nítorí èmi wà pẹ̀lú rẹ;
    má ṣe jẹ́ kí àyà kí ó fò ọ́, nítorí èmi ni Ọlọ́run rẹ.
Èmi yóò fún ọ lókun èmi ó sì ràn ọ́ lọ́wọ́.
    Èmi ó gbé ọ ró pẹ̀lú ọwọ́ ọ̀tún òdodo mi.

11 “Gbogbo àwọn tí ó bínú sí ọ
    ni ojú yóò tì, tí wọn yóò sì di ẹlẹ́yà;
àwọn tó ń bá ọ jà
    yóò dàbí asán, wọn yóò ṣègbé.
12 Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ yóò wá àwọn ọ̀tá rẹ,
    ìwọ kì yóò rí wọn.
Gbogbo àwọn tí ó gbóguntì ọ́
    yóò dàbí ohun tí kò sí.
13 Nítorí Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ,
    tí ó di ọwọ́ ọ̀tún rẹ mú
tí ó sì sọ fún ọ pé, má ṣe bẹ̀rù;
    Èmi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́.
14 Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu kòkòrò,
    ìwọ Israẹli kékeré,
nítorí Èmi fúnra mi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́,”
    ni Olúwa wí,
    olùdáǹdè rẹ, Ẹni Mímọ́ ti Israẹli.
15 “Kíyèsi, Èmi yóò sọ ọ́ di òòlù ìpakà tuntun,
    tí ó mú ti eyín rẹ̀ mú, ìwọ yóò lu àwọn òkè ńlá,
ìwọ yóò fọ́ wọn túútúú,
    a ó sì sọ òkè kékeré di ìyàngbò.
16 Ìwọ yóò fẹ́ wọn, afẹ́fẹ́ yóò sì gbá wọn mú,
    àti ẹ̀fúùfù yóò sì fẹ́ wọn dànù
Ṣùgbọ́n ìwọ yóò yọ̀ nínú Olúwa
    ìwọ yóò sì ṣògo nínú Ẹni Mímọ́ ti Israẹli.

17 “Àwọn tálákà àti aláìní wá omi,
    ṣùgbọ́n kò sí;
ahọ́n wọn gbẹ fún òǹgbẹ.
    Ṣùgbọ́n Èmi Olúwa yóò dá wọn lóhùn;
    Èmi, Ọlọ́run Israẹli, kì yóò kọ̀ wọ́n sílẹ̀.
18 Èmi yóò mú kí odò kí ó sàn ní ibi gíga
àti orísun omi ní àárín Àfonífojì.
    Èmi yóò sọ aṣálẹ̀ di adágún omi,
    àti ilẹ̀ tí ó gbẹ gidigidi di orísun omi.
19 Èmi yóò fi sínú aṣálẹ̀
    igi kedari àti kasia, maritili àti olifi.
Èmi yóò gbin junifa sí inú aginjù,
    igi firi àti sípírẹ́ṣì papọ̀
20 tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ènìyàn yóò fi rí i tí wọn yóò sì fi mọ̀,
    kí wọn ṣàkíyèsí kí ó sì yé wọn,
pé ọwọ́ Olúwa ni ó ti ṣe èyí,
    àti pé Ẹni Mímọ́ Israẹli ni ó ti dá èyí.

21 “Mú ẹjọ́ wá,” ni Olúwa wí.
    “Tẹ́ àwọn àwíjàre rẹ sílẹ̀,” ni ọba Jakọbu wí
22 “Mú àwọn ère òrìṣà rẹ wọlé láti sọ fún wa
    ohun tí yóò ṣẹlẹ̀.
Sọ fún wa ohun tí àwọn nǹkan àtijọ́ jẹ́,
    kí àwa lè ṣe àgbéyẹ̀wò wọn
kí àwa sì mọ àbájáde wọn ní ìparí.
    Tàbí kí o sọ fún wa ohun tí ó ń bọ̀ wá,
23 ẹ sọ fún wa ohun ti ọjọ́ iwájú mú dání
    kí àwa kí ó lè mọ̀ pé ọlọ́run ni yín.
Ẹ ṣe nǹkan kan, ìbá à ṣe rere tàbí búburú,
    tó bẹ́ẹ̀ tí àyà yóò fi fò wá tí ẹ̀rù yóò sì fi kún inú wa.
24 Ṣùgbọ́n ẹ̀yìn ko jásí nǹkan kan
    iṣẹ́ yín ni kò sì wúlò fún ohunkóhun;
    ẹni tí ó yàn yín jẹ́ ẹni ìríra.

25 “Èmi ti ru ẹnìkan sókè láti àríwá, òun sì ń bọ
    ẹnìkan láti ìlà-oòrùn tí ó pe orúkọ mi.
Òun gun àwọn aláṣẹ mọ́lẹ̀ bí ẹni pé odò ni wọ́n,
    àfi bí ẹni pé amọ̀kòkò nì ti ń gún amọ̀.
26 Ta ni ó sọ èyí láti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀, tí àwa kò bá fi mọ̀,
    tàbí ṣáájú àkókò, tí àwa kò bá fi wí pé, ‘Òun sọ òtítọ́’?
Ẹnikẹ́ni kò sọ nípa èyí,
    ẹnikẹ́ni kò sàsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀,
    ẹnikẹ́ni kò gbọ́ ọ̀rọ̀ kan láti ọ̀dọ̀ rẹ̀.
27 Èmi ni ẹni àkọ́kọ́ tí ó sọ fún Sioni pé, ‘Wò ó, àwọn nìyìí!’
    Mo fún Jerusalẹmu ní ìránṣẹ́ ìrò ìròyìn ayọ̀ kan.
28 Èmi wò, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan—
    kò sí ẹnìkan nínú wọn tí ó lè mú ìmọ̀ràn wá,
    kò sí ẹnìkan tí ó lè dáhùn nígbà tí mo bi wọ́n.
29 Kíyèsi i, irọ́ ni gbogbo wọn!
    Gbogbo ìṣe wọn jásí asán;
    àwọn ère wọn kò ṣé kò yà fún afẹ́fẹ́ àti dàrúdàpọ̀.

Ìránṣẹ́ Olúwa náà

42 (J)“Ìránṣẹ́ mi nìyìí, ẹni tí mo gbéró,
    àyànfẹ́ mi nínú ẹni tí mo láyọ̀;
Èmi yóò fi Ẹ̀mí mi sínú rẹ̀
    òun yóò sì mú ìdájọ́ wá sórí àwọn orílẹ̀-èdè.
Òun kì yóò pariwo tàbí kígbe sókè,
    tàbí kí ó gbóhùn rẹ̀ sókè ní òpópónà.
Koríko odò títẹ̀ kan ni òun kì yóò fọ́,
    àti òwú-fìtílà tí ń jó tan an lọ lòun kì yóò fẹ́ pa.
Ní òdodo ni yóò mú ìdájọ́ wá;
    òun kì yóò kọsẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni kò ní rẹ̀wẹ̀sì
títí tí yóò fi fi ìdájọ́ múlẹ̀ ní ayé.
    Nínú òfin rẹ̀ ni àwọn erékùṣù yóò fi ìrètí wọn sí.”

(K)Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run wí
    Ẹni tí ó dá àwọn ọ̀run tí ó sì tẹ́ wọ́n sóde,
tí ó tẹ́ ilẹ̀ ayé àti ohun gbogbo tí ó jáde nínú wọn,
    Ẹni tí ó fún àwọn ènìyàn rẹ̀ ní èémí
    àti ẹ̀mí fún gbogbo àwọn tí ń rìn nínú rẹ̀:
(L)“Èmi, Olúwa, ti pè ọ́ ní òdodo;
    Èmi yóò di ọwọ́ rẹ mú.
Èmi yóò pa ọ́ mọ́, n ó sì ṣe ọ́
    láti jẹ́ májẹ̀mú fún àwọn ènìyàn
    àti ìmọ́lẹ̀ fún àwọn aláìkọlà
(M)láti la àwọn ojú tí ó fọ́,
    láti tú àwọn òǹdè kúrò nínú túbú
àti láti tú sílẹ̀ kúrò nínú ẹ̀wọ̀n
    àwọn tí ó jókòó nínú òkùnkùn.

“Èmi ni Olúwa; orúkọ mi nìyìí!
    Èmi kì yóò fi ògo mi fún ẹlòmíràn
    tàbí ìyìn mi fún ère òrìṣà.
Kíyèsi i, àwọn nǹkan àtijọ́ ti wáyé,
    àti àwọn nǹkan tuntun ni mo ti wí pé;
kí wọn tó hù jáde
    mo ti kéde rẹ̀ fún ọ.”

Orin ìyìn sí Olúwa

10 Kọ orin tuntun sí Olúwa
    ìyìn rẹ̀ láti òpin ilẹ̀ ayé wá,
ẹ̀yin tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú Òkun, àti
    ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀
    ẹ̀yin erékùṣù, àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú wọn.
11 Jẹ́ kí aginjù àti àwọn ìlú rẹ̀ kí ó gbé ohùn wọn sókè;
    jẹ́ kí ibùdó ti àwọn igi Kedari ń gbé máa yọ̀.
Jẹ́ kí àwọn ènìyàn Sela kọrin fún ayọ̀;
    jẹ́ kí wọn pariwo láti orí òkè.
12 Jẹ́ kí wọn fi ògo fún Olúwa
    àti kí wọn sì kéde ìyìn rẹ̀ ní erékùṣù.
13 Olúwa yóò rìn jáde gẹ́gẹ́ bí i ọkùnrin alágbára,
    yóò ru owú sókè bí ológun;
yóò kígbe nítòótọ́, òun yóò ké igbe ogun,
    òun yóò sì ṣẹ́gun àwọn ọ̀tá rẹ̀.

14 “Fún ìgbà pípẹ́ ni mo ti dákẹ́ jẹ́ẹ́,
    mo ti wà ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, mo sì kó ara ró.
Ṣùgbọ́n ní àkókò yìí, gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó ń rọbí,
    mo sọkún, mo sì ń mí hẹlẹ hẹlẹ.
15 Èmi yóò sọ òkè ńlá àti kékeré di ahoro
    tí n ó sì gbẹ gbogbo ewéko rẹ̀ dànù;
Èmi yóò sọ àwọn odò di erékùṣù
    n ó sì gbẹ àwọn adágún.
16 Èmi yóò tọ àwọn afọ́jú ní ọ̀nà tí wọn kò tí ì mọ̀,
    ní ipa ọ̀nà tí ó ṣàjèjì sí wọn ni èmi yóò tọ́ wọn lọ;
Èmi yóò sọ òkùnkùn di ìmọ́lẹ̀ níwájú wọn
    àti ibi pálapàla ni èmi ó sọ di kíkúnná.
Àwọn nǹkan tí máa ṣe nìyìí;
    Èmi kì yóò kọ̀ wọ́n sílẹ̀.
17 Ṣùgbọ́n àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé òrìṣà,
    tí wọ́n wí fún ère pé, ‘Ẹ̀yin ni Ọlọ́run wa,’
    ni a ó dá padà pẹ̀lú ìtìjú.

Israẹli fọ́jú ó dití

18 “Gbọ́, ìwọ adití,
    wò ó, ìwọ afọ́jú, o sì rí!
19 Ta ló fọ́jú bí kò ṣe ìránṣẹ́ mi,
    àti odi gẹ́gẹ́ bí oníṣẹ́ tí mo rán?
Ta ni ó fọ́jú gẹ́gẹ́ bí ẹni tí a fi jìnmí,
    ó fọ́jú gẹ́gẹ́ bí ìránṣẹ́ Olúwa?
20 Ẹ̀yin ti rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan, ṣùgbọ́n ẹ kò ṣe àkíyèsí;
    etí yín yà sílẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ kò gbọ́ nǹkan kan.”
21 Ó dùn mọ́ Olúwa
    nítorí òdodo rẹ̀
    láti mú òfin rẹ lágbára àti ògo.
22 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn kan nìyìí tí a jà lógun
    tí a sì kó lẹ́rú,
gbogbo wọn ni ó wà nínú ọ̀gbun,
    tàbí tí a fi pamọ́ sínú ẹ̀wọ̀n.
Wọ́n ti di ìkógun,
    láìsí ẹnìkan tí yóò gbà wọ́n sílẹ̀;
wọ́n ti di ìkógun,
    láìsí ẹni tí yóò sọ pé, “Dá wọn padà.”

23 Ta ni nínú yín tí yóò tẹ́tí sí èyí
    tàbí kí ó ṣe àkíyèsí gidi ní àsìkò tí ó ń bọ̀?
24 Ta ni ó fi Jakọbu lélẹ̀ fún ìkógun,
    àti Israẹli sílẹ̀ fún onísùnmọ̀mí?
Kì í ha ṣe Olúwa ni,
    ẹni tí àwa ti ṣẹ̀ sí?
Nítorí pé wọn kò ní tẹ̀lé ọ̀nà rẹ̀;
    wọn kò mú òfin rẹ̀ ṣẹ.
25 Nítorí náà ni ó ṣe rọ̀jò ìbínú un rẹ̀ lé wọn lórí,
    rògbòdìyàn ogun.
Èyí tí ó fi ahọ́n iná yí wọn po, síbẹ̀
    èdè kò yé wọn;
    ó jó wọn run, síbẹ̀ wọn kò fi sọ́kàn wọn rárá.

Olùgbàlà Israẹli kan ṣoṣo

43 Ṣùgbọ́n ní ìsinsin yìí, ohun tí Olúwa wí nìyìí
    ẹni tí ó dá ọ, ìwọ Jakọbu
    ẹni tí ó mọ ọ́, Ìwọ Israẹli:
“Má bẹ̀rù, nítorí Èmi ti dá ọ nídè;
    Èmi ti pè ọ́ ní orúkọ; tèmi ni ìwọ ṣe.
Nígbà tí ìwọ bá ń la omi kọjá,
    Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ;
àti nígbà tí ìwọ bá ń la odò kọjá
    wọn kì yóò bò ọ́ mọ́lẹ̀.
Nígbà tí ìwọ bá la iná kọjá,
    kò ní jó ọ;
    ahọ́n iná kò ní jó ọ lára.
Nítorí Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ,
    Ẹni Mímọ́ Israẹli Olùgbàlà rẹ;
Èmi fi Ejibiti ṣe ìràpadà rẹ,
    Kuṣi àti Seba dípò rẹ.
Nítorí pé o ṣe iyebíye àti ọ̀wọ́n níwájú mi,
    àti nítorí pé mo fẹ́ràn rẹ,
Èmi yóò fi ènìyàn rọ́pò fún ọ,
    àti ènìyàn dípò ẹ̀mí rẹ.
Má bẹ̀rù nítorí èmi wà pẹ̀lú rẹ;
    Èmi yóò mú àwọn ọmọ rẹ láti ìlà-oòrùn wá
    èmi ó sì kó ọ jọ láti ìwọ̀-oòrùn.
Èmi yóò sọ fún àríwá pé, ‘Fi wọ́n sílẹ̀!’
    Àti fún gúúsù, ‘Má ṣe dá wọn dúró.’
Mú àwọn ọmọkùnrin mi láti ọ̀nà jíjìn wá
    àti àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin mi láti ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé—
ẹnikẹ́ni tí a ń pe orúkọ mi mọ́,
    tí mo dá fún ògo mi,
    tí mo mọ̀ àti tí mo ṣe.”

Sin àwọn tí ó ní ojú ṣùgbọ́n tí wọ́n fọ́jú jáde,
    tí wọ́n ní etí ṣùgbọ́n tí wọn dití.
Gbogbo orílẹ̀-èdè kó ra wọn jọ
    àwọn ènìyàn sì kó ra wọn papọ̀.
Ta ni nínú wọn tó sọ àsọtẹ́lẹ̀ yìí
    tí ó sì kéde fún wa àwọn nǹkan ti tẹ́lẹ̀?
Jẹ́ kí wọ́n mú àwọn ẹlẹ́rìí wọn wọlé wá
    láti fihàn pé wọ́n tọ̀nà
tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn mìíràn yóò gbọ́, tí
    wọn yóò sọ pé, “Òtítọ́ ni.”
10 “Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí mi,” ni Olúwa wí,
    “Àti ìránṣẹ́ mi tí èmi ti yàn,
tó bẹ́ẹ̀ tí ẹ̀yin yóò fi mọ̀ àti tí ẹ̀yin ó fi gbà mí gbọ́
    tí yóò sì yé e yín pé èmi ni ẹni náà.
Ṣáájú mi kò sí ọlọ́run tí a dá,
    tàbí a ó wa rí òmíràn lẹ́yìn mi.
11 Èmi, àní Èmi, Èmi ni Olúwa,
    yàtọ̀ sí èmi, kò sí olùgbàlà mìíràn.
12 Èmi ti fihàn, mo gbàlà mo sì ti kéde
    Èmi, kì í sì í ṣe àwọn àjèjì òrìṣà láàrín yín.
Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí mi,” ni Olúwa wí, “Pé Èmi ni Ọlọ́run.
13     Bẹ́ẹ̀ ni, àti láti ayérayé Èmi ni ẹni náà.
Kò sí ẹnikẹ́ni tí ó lè gbà kúrò lọ́wọ́ mi.
    Nígbà tí mo bá ṣe nǹkan, ta ni ó lè yí i padà?”

Àánú Ọlọ́run àti àìṣòdodo Israẹli

14 Èyí ni ohun tí Olúwa
    olùràpadà rẹ, Ẹni Mímọ́ ti Israẹli;
“Nítorí rẹ Èmi yóò ránṣẹ́ sí Babeli
    láti mú wọn sọ̀kalẹ̀ wá gẹ́gẹ́ bí ìsáǹsá,
gbogbo ará Babeli
    nínú ọkọ̀ ojú omi nínú èyí tí wọ́n fi ń ṣe ìgbéraga.
15 Èmi ni Olúwa, Ẹni Mímọ́ rẹ,
    Ẹlẹ́dàá Israẹli, ọba rẹ.”

16 Èyí ni ohun tí Olúwa
    Ẹni náà tí ó la ọ̀nà nínú Òkun,
    ipa ọ̀nà láàrín alagbalúgbú omi,
17 ẹni tí ó wọ́ àwọn kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin jáde,
    àwọn jagunjagun àti ohun ìjà papọ̀,
wọ́n sì sùn síbẹ̀, láìní lè dìde mọ́,
    wọ́n kú pirá bí òwú-fìtílà:
18 “Gbàgbé àwọn ohun àtẹ̀yìnwá;
    má ṣe gbé nínú ohun àtijọ́.
19 Wò ó, Èmi ń ṣe ohun tuntun!
    Nísinsin yìí ó ti yọ sókè; àbí o kò rí i bí?
Èmi ń ṣe ọ̀nà kan nínú aṣálẹ̀
    àti odò nínú ilẹ̀ ṣíṣá.
20 Àwọn ẹhànnà ẹranko bọ̀wọ̀ fún mi,
    àwọn ajáko àti àwọn òwìwí,
nítorí pé mo pèsè omi nínú aṣálẹ̀
    àti odò nínú ilẹ̀ sísá,
láti fi ohun mímu fún àwọn ènìyàn mi, àyànfẹ́ mi,
21     àwọn ènìyàn tí mo dá fún ara mi
    kí wọn kí ó lè kéde ìyìn mi.

22 “Síbẹ̀síbẹ̀ ìwọ kò tí ì ké pè mí,
    ìwọ Jakọbu,
àárẹ̀ kò tí ì mú ọ nítorí mi
    ìwọ Israẹli.
23 Ìwọ kò tí ì mú àgùntàn wá fún mi fún ẹbọ sísun,
    tàbí kí o bọ̀wọ̀ fún mi pẹ̀lú ẹbọ rẹ.
Èmi kò tí ì wàhálà rẹ pẹ̀lú ọrẹ ìyẹ̀fun
    tàbí kí n dààmú rẹ pẹ̀lú ìbéèrè fún tùràrí.
24 Ìwọ kò tí ì ra kalamusi olóòórùn dídùn fún mi,
    tàbí kí o da ọ̀rá ẹbọ rẹ bò mí.
Ṣùgbọ́n ẹ ti wàhálà mi pẹ̀lú ẹ̀ṣẹ̀ yín
    ẹ sì ti dààmú mi pẹ̀lú àìṣedéédéé yín.

25 “Èmi, àní Èmi, Èmi ni ẹni tí ó wẹ
    àwọn àìṣedéédéé rẹ nù, nítorí èmi fún ara mi,
    tí n kò sì rántí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ mọ́.
26 Bojú wo ẹ̀yìn rẹ fún mi,
    jẹ́ kí a jọ ṣe àríyànjiyàn ọ̀rọ̀ náà papọ̀;
    ro ẹjọ́ láti fihàn pé o kò lẹ́sẹ̀ lọ́rùn.
27 Baba yín àkọ́kọ́ dẹ́ṣẹ̀;
    àwọn agbẹnusọ yín ṣọ̀tẹ̀ sí mi.
28 Nítorí náà, èmi ti sọ àwọn olórí ibi mímọ́ náà di àìmọ́,
    bẹ́ẹ̀ ni èmi ti fi Jakọbu fún ègún
    àti Israẹli fún ẹ̀gàn.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)

Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.