Print Page Options
Previous Prev Day Next DayNext

Chronological

Read the Bible in the chronological order in which its stories and events occurred.
Duration: 365 days
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Version
Isaiah 23-27

Àsọtẹ́lẹ̀ kan nípa Tire

23 (A)Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Tire:

Hu, ìwọ ọkọ̀ ojú omi Tarṣiṣi!
    Nítorí a ti pa Tire run
láìsí ilé tàbí èbúté.
    Láti ilẹ̀ Saipurọsi ni
    ọ̀rọ̀ ti wá sọ́dọ̀ wọn.

Dákẹ́ jẹ́ẹ́, ẹ̀yin ènìyàn erékùṣù
    àti ẹ̀yin oníṣòwò ti Sidoni,
    ẹ̀yin tí àwọn a wẹ Òkun ti sọ dọlọ́rọ̀.
Láti orí àwọn omi ńlá
    ni irúgbìn ìyẹ̀fun ti ilẹ̀ Ṣihori ti wá
ìkórè ti odò Naili ni owóòná Tire,
    òun sì ti di ibùjókòó ọjà fún
    àwọn orílẹ̀-èdè.

Kí ojú kí ó tì ọ́, ìwọ Sidoni àti ìwọ
    àní ìwọ ilé ààbò ti Òkun,
nítorí Òkun ti sọ̀rọ̀:
    “Èmi kò tí ì wà ní ipò ìrọbí tàbí ìbímọ rí
Èmi kò tí ì wo àwọn ọmọkùnrin
    tàbí kí n tọ́ àwọn ọmọbìnrin dàgbà rí.”
Nígbà tí ọ̀rọ̀ bá dé Ejibiti,
    wọn yóò wà ní ìpayínkeke nípa
    ìròyìn láti Tire.

Kọjá wá sí Tarṣiṣi;
    pohùnréré, ẹ̀yin ènìyàn erékùṣù.
Ǹjẹ́ èyí náà ni ìlú àríyá yín,
    ògbólógbòó ìlú náà,
èyí tí ẹsẹ̀ rẹ̀ ti sìn ín lọ
    láti lọ tẹ̀dó sí ilẹ̀ tí ó jìnnà réré.
Ta ló gbèrò èyí sí Tire,
    ìlú aládé,
àwọn oníṣòwò ẹni tí ó jẹ́ ọmọ-aládé
    tí àwọn oníṣòwò wọ́n jẹ́ ìlúmọ̀míká
    ní orílẹ̀ ayé?
Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti ṣètò rẹ̀,
    láti tẹrí ìgbéraga àti ògo rẹ ba
àti láti rẹ gbogbo àwọn ọlọ́lá
    ilé ayé sílẹ̀.

10 Tu ilẹ̀ rẹ gẹ́gẹ́ bí i ti ipadò odò Ejibiti,
    Ìwọ ọmọbìnrin Tarṣiṣi,
    nítorí ìwọ kò ní èbúté mọ́.
11 Olúwa ti na ọwọ́ rẹ̀ jáde sí orí Òkun
    ó sì mú kí àwọn ilẹ̀ ọba wárìrì.
Ó ti pa àṣẹ kan tí ó kan Kenaani
    pé kí a pa ilé ààbò rẹ̀ run.
12 Ó wí pé, “Kò sí àríyá fún ọ mọ́”
    ìwọ wúńdíá ti Sidoni, tí a ti tẹ̀ mọ́lẹ̀ báyìí!

“Gbéra, rékọjá lọ sí Saipurọsi,
    níbẹ̀ pẹ̀lú o kì yóò ní ìsinmi.”
13 Bojú wo ilẹ̀ àwọn ará Babeli,
    àwọn ènìyàn tí kò jámọ́ nǹkan kan báyìí
Àwọn Asiria ti sọ ọ́ di
    ibùgbé àwọn ohun ẹranko aginjù;
wọn ti gbé ilé ìṣọ́ ìtẹ̀gùn wọn sókè,
    wọ́n ti tú odi rẹ̀ sí ìhòhò
    wọ́n sì ti sọ ọ́ di ààtàn.

14 Hu, ìwọ ọkọ̀ ojú omi Tarṣiṣi;
    wọ́n ti pa odi rẹ̀ run!

15 Ní àkókò náà a ó gbàgbé Tire fún àádọ́rin ọdún, ọjọ́ ayé ọba kan. Ṣùgbọ́n ní òpin àádọ́rin ọdún wọ̀nyí, yóò ṣẹlẹ̀ sí Tire gẹ́gẹ́ bí orin àgbèrè:

16 “Mú dùùrù kan, rìn kọjá láàrín ìlú,
    Ìwọ àgbèrè tí a ti gbàgbé;
lu dùùrù dáradára, kọ ọ̀pọ̀ orin,
    kí a lè ba à rántí rẹ.”

17 (B)Ní òpin àádọ́rin ọdún náà, Olúwa yóò bá Tire jà. Òun yóò sì padà sí àyálò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí panṣágà, yóò sì máa ṣe òwò rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ilẹ̀ ọba tí ó wà ní ilẹ̀ ayé. 18 Síbẹ̀síbẹ̀ èrè rẹ̀ àti owó iṣẹ́ rẹ̀ ni a ó yà sọ́tọ̀ fún Olúwa; a kò ní kó wọn pamọ́ tàbí kí a há wọn mọ́wọ́. Ère rẹ̀ ni a ó fi fún àwọn tí ó ń gbé níwájú Olúwa, fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ oúnjẹ àti aṣọ.

Ìparun Olúwa lórí ilẹ̀ ayé

24 Kíyèsi i, Olúwa yóò sọ ohun
    gbogbo dòfo ní ilẹ̀ ayé
yóò sì pa á run
    òun yóò pa ojú u rẹ̀ rẹ́
    yóò sì fọ́n àwọn olùgbé ibẹ̀ káàkiri—
bákan náà ni yóò sì rí
    fún àlùfáà àti àwọn ènìyàn,
fún ọ̀gá àti ọmọ ọ̀dọ̀,
    fún ìyá-ilé àti ọmọbìnrin,
fún olùtà àti olùrà,
    fún ayáni àti atọrọ
    fún ayánilówó àti onígbèsè.
Ilé ayé ni a ó sọ di ahoro pátápátá
    a ó sì jẹ gbogbo rẹ̀ run.
    Olúwa ni ó ti sọ ọ̀rọ̀ yìí.

Ilẹ̀ ayé ti gbẹ ó sì sá,
    ayé ń ṣòjòjò, àárẹ̀ mú un,
    àwọn ẹni gíga ilẹ̀ ayé wà nínú ìpọ́njú
àwọn ènìyàn ayé ti bà á jẹ́;
    wọ́n ti pa àwọn òfin run
wọ́n ṣe lòdì sí àwọn ìlànà
    wọ́n sì ti ba májẹ̀mú ayérayé jẹ́.
Nítorí náà, ègún kan ti jẹ ayé run;
    àwọn ènìyàn rẹ̀ ní láti ru ẹ̀bi wọn.
Nítorí náà, àwọn olùgbé ayé ti gbiná dànù,
    àwọn ẹ̀tàhóró ló sì kù.
Wáìnì tuntun ti gbẹ, àjàrà sì ti rọ,
    gbogbo àwọn aláríyá sì kérora.
(C)Àríyá ti ṣaworo ti dákẹ́
    ariwo àwọn tí ń ṣàjọyọ̀ ti dáwọ́ dúró
    ayọ̀ dùùrù ti dákẹ́ jẹ́ẹ́.
Kò ṣe é ṣe fún wọn láti máa mu wáìnì pẹ̀lú orin kíkọ mọ́
    ọtí líle ti di ìkorò fún àwọn ọ̀mu.
10 Ìlú tí a run ti dahoro,
    ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé kọ̀ọ̀kan ni a dí pa.
11 Ní òpópónà ni wọ́n ti ń kígbe fún wáìnì
    gbogbo ayọ̀ ọ wọn ti di ìbànújẹ́,
    gbogbo àríyá ni a lé kúrò lórí ilẹ̀ ayé.
12 Ìlú ni a ti fi sílẹ̀ ní ahoro,
    ìlẹ̀kùn rẹ̀ ni a sì tì pa bámú bámú.
13 Bẹ́ẹ̀ ni yóò sì rí ní orí ilẹ̀ ayé
    àti láàrín àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú,
gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí a lu igi olifi,
    tàbí gẹ́gẹ́ bí i pàǹtí tí ó ṣẹ́kù lẹ́yìn
    tí a kórè èso tán.

14 Wọ́n gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì hó fún ayọ̀;
    láti ìwọ̀-oòrùn ni wọn yóò ti polongo
    ọláńlá Olúwa.
15 Nítorí náà ní ìlà-oòrùn ẹ fi ògo fún Olúwa;
    gbé orúkọ Olúwa ga, àní
Ọlọ́run Israẹli,
    ní àwọn erékùṣù ti inú Òkun,
16 Láti òpin ayé wá ni a ti gbọ́ orin;
    “Ògo ni fún olódodo n nì.”
    Ṣùgbọ́n mo wí pé, “Mo ṣègbé, mo ṣègbé!

“Ègbé ni fún mi!
    Alárékérekè dalẹ̀!
    Pẹ̀lú ìhàlẹ̀ ni àgàbàgebè fi dalẹ̀!”
17 Ìpayà, isà òkú, àti ìdẹ̀kùn ń dúró dè ọ́,
    ìwọ ènìyàn ilẹ̀ ayé.
18 Ẹnikẹ́ni tí ó bá sá nítorí ariwo ìpayà
    yóò ṣubú sínú ihò,
ẹnikẹ́ni tí ó bá sì yọ́ jáde nínú ihò
    ni ìdẹ̀kùn yóò gbámú.

Ibodè ọ̀run ti wà ní ṣíṣí sílẹ̀
    Ìpìlẹ̀ ayé mì tìtì.
19 Ilẹ̀ ayé ti fọ́
    ilẹ̀ ayé ti fọ́ dànù,
    a ti mi ilẹ̀ ayé rìrìrìrì.
20 Ilẹ̀ ayé yí gbiri bí ọ̀mùtí,
    ó bì síwá sẹ́yìn bí ahéré nínú afẹ́fẹ́;
Ẹ̀bi ìṣọ̀tẹ̀ rẹ̀ ń pa á lẹ́rù
    tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi ṣubú láìní lè dìde mọ́.

21 Ní ọjọ́ náà ni Olúwa yóò jẹ ẹ́ ní yà
    gbogbo agbára tí ó wà lókè lọ́run
    àti àwọn ọba tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé.
22 A ó sì kó wọn jọ pọ̀,
    gẹ́gẹ́ bí ará túbú jọ sínú ihò,
a ó tì wọ́n mọ́ inú túbú,
    a ó sì bẹ̀ wọ́n wò lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́.
23 A ó rẹ òṣùpá sílẹ̀, ojú yóò sì ti oòrùn;
    nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò jẹ ọba
ní orí òkè Sioni àti ní Jerusalẹmu,
    àti níwájú àwọn àgbàgbà rẹ ní ògo.

Ẹ yin Olúwa

25 Olúwa, ìwọ ni Ọlọ́run mi;
    Èmi yóò gbé ọ ga èmi ó sì
fi ìyìn fún orúkọ rẹ
    nítorí nínú òtítọ́ aláìlẹ́gbẹ́
o ti ṣe ohun ńlá,
    àwọn ohun tí o ti gbèrò o rẹ̀ lọ́jọ́ pípẹ́.
Ìwọ ti sọ ìlú di àkójọ àlàpà,
    ìlú olódi ti di ààtàn,
ìlú olódi fún àwọn àjèjì ni kò sí mọ́;
    a kì yóò tún un kọ́ mọ́.
Nítorí náà àwọn ènìyàn alágbára yóò
    bọ̀wọ̀ fún ọ;
àwọn ìlú orílẹ̀-èdè aláìláàánú
    yóò bu ọlá fún ọ.
Ìwọ ti jẹ́ ààbò fún àwọn òtòṣì
    ààbò fún aláìní nínú ìpọ́njú rẹ̀
ààbò kúrò lọ́wọ́ ìjì
    bòòji kúrò lọ́wọ́ ooru.
Nítorí pé èémí àwọn ìkà
    dàbí ìjì tí ó bì lu ògiri
àti gẹ́gẹ́ bí ooru ní aginjù.
    O mú ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ bá rògbòdìyàn àwọn àjèjì,
gẹ́gẹ́ bí òjìji kurukuru ṣe ń dín ooru kù,
    bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni orin àwọn ìkà yóò dákẹ́.

Ní orí òkè yìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun
    yóò ti pèsè
àsè oúnjẹ àdídùn kan fún gbogbo ènìyàn
    àpèjẹ ti ọtí wáìnì àtijọ́
ti ẹran tí ó dára jù àti ti ọtí wáìnì
    tí ó gbámúṣé.
Ní orí òkè yìí ni yóò pa
    aṣọ òkú tí ó ti ń di gbogbo ènìyàn,
    abala tí ó bo gbogbo orílẹ̀-èdè mọ́lẹ̀;
(D)Òun yóò sì gbé ikú mì títí láé.
    Olúwa Olódùmarè yóò sì nu gbogbo omijé nù,
kúrò ní ojú gbogbo wọn;
    Òun yóò sì mú ẹ̀gàn àwọn ènìyàn rẹ̀ kúrò
ní gbogbo ilẹ̀ ayé.
    Olúwa ni ó ti sọ ọ́.

Ní ọjọ́ náà wọn yóò sọ pé,

    “Nítòótọ́ eléyìí ni Ọlọ́run wa;
àwa ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú rẹ̀, òun sì gbà wá là.
    Èyí ni Olúwa, àwa gbẹ́kẹ̀lé e,
    ẹ jẹ́ kí a yọ̀ kí inú wa sì dùn nínú ìgbàlà rẹ̀.”
10 (E)Ọwọ́ Olúwa yóò sinmi lé orí òkè yìí
    ṣùgbọ́n a ó tẹ Moabu mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀;
    gẹ́gẹ́ bí a ti gún koríko mọ́lẹ̀ di ajílẹ̀.
11 Wọn yóò na ọwọ́ wọn jáde nínú rẹ̀,
    gẹ́gẹ́ bí òmùwẹ̀ tí ń na ọwọ́ rẹ̀
jáde láti lúwẹ̀ẹ́.
    Ọlọ́run yóò mú ìgbéraga wọn wálẹ̀
    bó tilẹ̀ jẹ́ pé ìṣeféfé wà ní ọwọ́ wọn.
12 Òun yóò sì bi gbogbo ògiri gíga alágbára yín lulẹ̀
    wọn yóò sì wà nílẹ̀
Òun yóò sì mú wọn wá si ilẹ̀,
    àní sí erùpẹ̀ lásán.

Orin ìyìn kan

26 Ní ọjọ́ náà ni a ó kọ orin yìí ní ilẹ̀ Juda:

Àwa ní ìlú alágbára kan,
    Ọlọ́run fi ìgbàlà ṣe
    ògiri àti ààbò rẹ̀.
Ṣí àwọn ìlẹ̀kùn
    kí àwọn olódodo orílẹ̀-èdè kí ó lè wọlé,
    orílẹ̀-èdè tí ó pa ìgbàgbọ́ mọ́.
Ìwọ yóò pa á mọ́ ní àlàáfíà pípé
    ọkàn ẹni tí ó dúró ṣinṣin,
    nítorí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ.
Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa títí láé,
    nítorí Olúwa, Olúwa ni àpáta
    ayérayé náà.
Ó sọ àwọn tí ó ń gbé ní òkè di onírẹ̀lẹ̀
    ó rẹ ìlú agbéraga náà nílẹ̀;
ó sọ ọ́ di ilẹ̀ pẹrẹsẹ
    ó sì sọ ọ́ sílẹ̀ nínú erùpẹ̀.
Ẹsẹ̀ tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀
    ẹsẹ̀ aninilára n nì,
    ipasẹ̀ àwọn òtòṣì.

Ipa ọ̀nà àwọn olódodo tẹ́jú
    Ìwọ tó dúró ṣinṣin, ìwọ mú ọ̀nà
    àwọn olódodo ṣe geere.
Bẹ́ẹ̀ ni, Olúwa, rírìn ní ọ̀nà òfin rẹ
    àwa dúró dè ọ́;
orúkọ rẹ àti òkìkí rẹ
    àwọn ni ohun tí ọkàn wa ń fẹ́.
Ọkàn mi ń pòùngbẹẹ̀ rẹ ní ọ̀gànjọ́ òru;
    ní òwúrọ̀ ni ẹ̀mí mi ń ṣàfẹ́rí rẹ.
Nígbà tí ìdájọ́ rẹ bá sọ̀kalẹ̀ sórí ayé
    àwọn ènìyàn yóò kọ́ ìṣòdodo.
10 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a fi oore-ọ̀fẹ́ hàn sí àwọn ìkà
    wọn kò kọ́ láti sọ òdodo;
kódà ní ilẹ̀ àwọn tí ó dúró ṣinṣin wọ́n
    tẹ̀síwájú láti máa ṣe ibi
    wọn kò sì ka ọláńlá Olúwa sí.
11 Olúwa, ti gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè
    ṣùgbọ́n àwọn kò rí i.
Jẹ́ kí wọ́n rí ìtara rẹ fún àwọn ènìyàn rẹ
    kí ojú kí ó tì wọ́n;
jẹ́ kí iná tí a fi pamọ́ fún àwọn
    ọ̀tá rẹ jó wọn run.

12 Olúwa, ìwọ fi àlàáfíà lélẹ̀ fún wa;
    ohun gbogbo tí a ti ṣe yọrí ìwọ ni
    ó ṣe é fún wa.
13 Olúwa Ọlọ́run wa, àwọn olúwa mìíràn
    lẹ́yìn rẹ ti jẹ ọba lé wa lórí,
    ṣùgbọ́n orúkọ rẹ nìkan ni àwa fi ọ̀wọ̀ fún.
14 Wọ́n ti kú báyìí, wọn ò sí láààyè mọ́;
    gbogbo ẹ̀mí tí ó ti kọjá lọ wọ̀nyí kò le dìde mọ́.
Ìwọ jẹ́ wọ́n ní ìyà o sì sọ wọ́n di asán,
    Ìwọ pa gbogbo ìrántí wọn rẹ́ pátápátá.
15 Ìwọ ti mú orílẹ̀-èdè gbòòrò, Olúwa;
    ìwọ ti mú orílẹ̀-èdè bí sí i.
Ìwọ ti gba ògo fún ara rẹ;
    ìwọ ti sún gbogbo àwọn ààlà ilẹ̀ sẹ́yìn.

16 Olúwa, wọ́n wá sọ́dọ̀ rẹ nínú ìpọ́njú wọn;
    nígbà tí ìbáwí rẹ wà lára wọn,
    wọ́n gbàdúrà kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́.
17 Gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó lóyún tí ó sì fẹ́rẹ̀ bímọ
    tí í rúnra tí ó sì ń sọkún nínú ìrora rẹ̀,
    bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni àwa rí níwájú rẹ Olúwa.
18 Àwa wà nínú oyún, a wà nínú ìrora
    ṣùgbọ́n, afẹ́fẹ́ ni a bí lọ́mọ.
Àwa kò mú ìgbàlà wá sí ilẹ̀ ayé;
    àwa kọ́ ni a bí àwọn ènìyàn tí ó wà láyé.

19 Ṣùgbọ́n àwọn òkú yín yóò wà láààyè
    ara wọn yóò dìde.
Ìwọ tí o wà nínú erùpẹ̀,
    dìde nílẹ̀ kí o sì ké igbe ayọ̀.
Ìrì rẹ dàbí ìrì òwúrọ̀,
    ayé yóò bí àwọn òkú rẹ̀ lọ́mọ.

20 Ẹ lọ, ẹ̀yin ènìyàn mi, ẹ wọ ìyẹ̀wù yín lọ
    kí ẹ sì ti àwọn ìlẹ̀kùn lẹ́yìn yín,
ẹ fi ara yín pamọ́ fún ìgbà díẹ̀
    títí tí ìbínú rẹ̀ yóò fi rékọjá.
21 Kíyèsi i, Olúwa ń jáde bọ̀ láti ibùgbé rẹ̀
    láti jẹ àwọn ènìyàn ilẹ̀ ayé ní
ìyà fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
    Ayé yóò sì sọ àwọn ẹ̀jẹ̀ tí a ta sí orí rẹ̀,
    kì yóò sì fi àwọn tí a ti pa pamọ́ mọ́.

Ìdáǹdè Israẹli

27 Ní ọjọ́ náà,

Olúwa yóò fi idà rẹ̀ jẹ ni ní yà
    idà rẹ̀ a mú bí iná tí ó tóbi tí ó sì lágbára
Lefitani ejò tí ń yọ̀ tẹ̀ẹ̀rẹ̀ n nì,
    Lefitani ejò tí ń lọ́ bìrìkìtì;
    Òun yóò sì pa ẹ̀mí búburú inú Òkun náà.

Ní ọjọ́ náà

“Kọrin nípa ọgbà àjàrà eléso kan.
    Èmi Olúwa ń bojútó o,
Èmi ó bomirin ín láti ìgbàdégbà.
    Èmi ó ṣọ́ ọ tọ̀sán tòru
    kí ẹnikẹ́ni má ba à pa á lára.
Inú kò bí mi.
    Bí ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n bá dojú ìjà kọ mí!
Èmi yóò dìde sí wọn ní ogun;
    Èmi yóò sì dáná sun gbogbo wọn.
Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, jẹ́ kí wọn wá sọ́dọ̀ mi fún ààbò;
    jẹ́ kí wọ́n wá àlàáfíà pẹ̀lú mi,
    bẹ́ẹ̀ ni, jẹ́ kí wọn wá àlàáfíà pẹ̀lú mi.”

Ní ọjọ́ iwájú Jakọbu yóò ta gbòǹgbò,
    Israẹli yóò tanná yóò sì rudi
    èso rẹ̀ yóò sì kún gbogbo ayé.

Ǹjẹ́ Olúwa ti lù ú
    gẹ́gẹ́ bí ó ti lu àwọn tí ó lù ú bolẹ̀?
Ǹjẹ́ a ti pa á
    gẹ́gẹ́ bí a ti pa àwọn tí ó pa á?
Nípa ogun jíjà àti ìjìyà ti o le ni ó
    fi dojúkọ ọ́
pẹ̀lú ìjì gbígbóná ni ó lé e jáde,
    gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ tí afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn fẹ́
Nítorí èyí báyìí ni ètùtù yóò ṣe wà
    fún ẹ̀ṣẹ̀ Jakọbu,
èyí ni yóò sì jẹ́ èso kíkún ti
    ìmúkúrò ẹ̀ṣẹ̀ rẹ:
Nígbà tí ó bá mú kí àwọn òkúta pẹpẹ
    dàbí òkúta ẹfun tí a fọ́ sí wẹ́wẹ́,
kì yóò sí ère Aṣerah tàbí pẹpẹ tùràrí
    tí yóò wà ní ìdúró.
10 Ìlú olódi náà ti dahoro,
    ibùdó ìkọ̀sílẹ̀, tí a kọ̀ tì
gẹ́gẹ́ bí aginjù;
    níbẹ̀ ni àwọn ọmọ màlúù ti ń jẹ oko
níbẹ̀ ni wọn ń sùn sílẹ̀;
    wọn sì jẹ gbogbo ẹ̀ka rẹ̀ tán.
11 Nígbà tí àwọn ẹ̀ka rẹ̀ bá rọ, a ó ya wọn dànù
    àwọn obìnrin dé, wọ́n sì fi wọ́n dáná
nítorí aláìlóye ènìyàn ni wọn jẹ́;
    Nítorí náà ni ẹni tí ó dá wọn kì yóò ṣàánú fún wọn;
    bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó mọ wọn kì yóò sì fi ojúrere wò wọ́n.

12 Ní ọjọ́ náà Olúwa yóò sì kó oore láti ìṣàn omi odo Eufurate wá títí dé Wadi ti Ejibiti, àti ìwọ, ìwọ ọmọ Israẹli, ni a ó kójọ ní ọ̀kọ̀ọ̀kan. 13 (F)Àti ní ọjọ́ náà, a ó fun fèrè ńlá kan. Gbogbo àwọn tí ń ṣègbé lọ ní Asiria àti àwọn tí ń ṣe àtìpó ní Ejibiti yóò wá sin Olúwa ní òkè mímọ́ ní Jerusalẹmu.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)

Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.