Print Page Options
Previous Prev Day Next DayNext

Chronological

Read the Bible in the chronological order in which its stories and events occurred.
Duration: 365 days
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Version
Isaiah 18-22

Àsọtẹ́lẹ̀ lòdì sí Kuṣi

18 (A)Ègbé ni fún ilẹ̀ tí ó kún fún ariwo ìyẹ́ eṣú,
    ní àwọn ipadò Kuṣi,
tí ó rán àwọn ikọ̀ lórí Òkun
    lórí omi nínú ọkọ̀-ọpọ́n tí a fi eèsún papirusi ṣe.

Ẹ lọ, ẹ̀yin ikọ̀ tí ó yára,
    sí àwọn ènìyàn gíga tí àwọ̀ ara wọn jọ̀lọ̀,
sí àwọn ènìyàn tí a ń bẹ̀rù káàkiri,
    orílẹ̀-èdè aláfojúdi alájèjì èdè,
    tí odò pín ilẹ̀ rẹ̀ yẹ́lẹyẹ̀lẹ.

Gbogbo ẹ̀yin ènìyàn ayé,
    tí ó ń gbé orílẹ̀ ayé,
nígbà tí a bá gbé àsíá kan sókè lórí òkè,
    ẹ ó rí i,
nígbà tí a bá fun fèrè kan
    ẹ ó gbọ́ ọ.
Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún mi:
    “Èmi yóò dákẹ́ jẹ́ẹ́, èmi yóò sì máa wo òréré
láti ibùgbé e mi wá,
    gẹ́gẹ́ bí ooru gbígbóná nínú ìtànṣán oòrùn,
    gẹ́gẹ́ bí òjò-dídì ní àárín gbùngbùn ìkórè.”
Nítorí, kí ìkórè tó bẹ̀rẹ̀,
    nígbà tí ìrudí bá kún,
nígbà tí ìtànná bá di èso àjàrà pípọ́n.
    Òun yóò sì fi dòjé rẹ́ ẹ̀ka tuntun,
yóò sì mu kúrò,
    yóò sì gé ẹ̀ka lulẹ̀.
A ó fi wọ́n sílẹ̀ fún àwọn ẹyẹ òkè ńlá
    àti fún àwọn ẹranko búburú;
àwọn ẹyẹ yóò fi wọ́n ṣe oúnjẹ nínú ẹ̀ẹ̀rùn
    àti àwọn ẹranko búburú nígbà òjò.

Ní àkókò náà ni a ó mú ẹ̀bùn wá fún Olúwa àwọn ọmọ-ogun

láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn gíga tí ẹran-ara wọn jọ̀lọ̀,
    láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn tí a bẹ̀rù níbi gbogbo,
orílẹ̀-èdè aláfojúdi àti alájèjì èdè,
    ilẹ̀ ẹni tí omi pín sí yẹ́lẹyẹ̀lẹ—

a ó mú àwọn ẹ̀bùn náà wá sí òkè Sioni, ibi tí orúkọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun gbé wà.

Àsọtẹ́lẹ̀ lòdì sí Ejibiti

19 (B)Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Ejibiti:

Kíyèsi i, Olúwa gun àwọsánmọ̀ tí ó yára lẹ́ṣin
    ó sì ń bọ̀ wá sí Ejibiti.
Àwọn ère òrìṣà Ejibiti wárìrì níwájú rẹ̀,
    ọkàn àwọn ará Ejibiti sì ti domi nínú wọn.

“Èmi yóò rú àwọn ará Ejibiti sókè sí ara wọn
    arákùnrin yóò bá arákùnrin rẹ̀ jà,
aládùúgbò yóò dìde sí aládùúgbò rẹ̀,
    ìlú yóò dìde sí ìlú,
    ilẹ̀ ọba sí ilẹ̀ ọba.
Àwọn ará Ejibiti yóò sọ ìrètí nù,
    èmi yóò sì sọ èrò wọn gbogbo di òfo;
wọn yóò bá àwọn òrìṣà àti ẹ̀mí àwọn òkú sọ̀rọ̀,
    àwọn awoṣẹ́ àti àwọn abókùúsọ̀rọ̀.
Èmi yóò fi Ejibiti lé agbára
    àwọn ìkà amúnisìn lọ́wọ́,
ọba aláìláàánú ni yóò jẹ ọba lé wọn lórí,”
    ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

Gbogbo omi inú odò ni yóò gbẹ,
    gbogbo ilẹ̀ àyíká odò ni yóò gbẹ tí yóò sì sáàpá.
Adágún omi yóò sì di rírùn;
    àwọn odò ilẹ̀ Ejibiti yóò máa dínkù
wọn yóò sì gbẹ.
    Àwọn koríko odò àti ìrẹ̀tẹ̀ yóò gbẹ,
àwọn igi ipadò Naili pẹ̀lú,
    tí ó wà ní orísun odò,
gbogbo oko tí a dá sí ipadò Naili
    yóò gbẹ dànù tí yóò sì fẹ́ dànù
    tí kò sì ní sí mọ́.
Àwọn apẹja yóò sọkún kíkorò,
    àti gbogbo àwọn tí ó ń ju ìwọ̀ sínú odò;
    odò náà yóò sì máa rùn.
Àwọn tí ó ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ọ̀gbọ̀ yóò kọminú
    àwọn ahunṣọ ọ̀gbọ̀ yóò sọ ìrètí nù.
10 Àwọn tí ń ṣiṣẹ́ aṣọ yóò rẹ̀wẹ̀sì,
    gbogbo àwọn oníṣẹ́ oṣù ni àìsàn ọkàn yóò ṣe.

11 Àwọn oníṣẹ́ Ṣoani ti di aláìgbọ́n,
    àwọn ọlọ́gbọ́n olùdámọ̀ràn Farao
ń mú ìmọ̀ràn àìgbọ́n wá.
    Báwo ló ṣe lè sọ fún Farao pé,
“Mo jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn,
    ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn àwọn ọba àtijọ́.”

12 Níbo ni àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn rẹ wà báyìí?
    Jẹ́ kí wọn fihàn ọ́ kí wọn sì sọ ọ́ di mí mọ̀
ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun
    ti pinnu lórí Ejibiti.
13 Àwọn ọmọ-aládé Ṣoani ti di aṣiwèrè,
    a ti tan àwọn ọmọ-aládé Memfisi jẹ;
àwọn òkúta igun ilé tí í ṣe ti ẹ̀yà rẹ
    ti ṣi Ejibiti lọ́nà.
14 Olúwa ti da ẹ̀mí òòyì sínú wọn;
    wọ́n mú Ejibiti ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n nínú
ohun gbogbo tí ó ń ṣe,
    gẹ́gẹ́ bí ọ̀mùtí ti í ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n nínú èébì rẹ̀.
15 Kò sí ohun tí Ejibiti le ṣe—
    orí tàbí ìrù, ọ̀wá ọ̀pẹ tàbí koríko odò.

16 Ní ọjọ́ náà ni àwọn ará Ejibiti yóò dàbí obìnrin. Wọn yóò gbọ̀n jìnnìjìnnì pẹ̀lú ẹ̀rù nítorí ọwọ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun tí a gbé sókè sí wọn. 17 Ilẹ̀ Juda yóò sì di ẹ̀rù fún Ejibiti; gbogbo àwọn tí a bá ti dárúkọ Juda létí wọn ni yóò wárìrì, nítorí ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun gbèrò láti ṣe sí wọn.

18 Ní ọjọ́ náà ìlú márùn-ún ní ilẹ̀ Ejibiti yóò sọ èdè àwọn ará Kenaani, wọn yóò sì búra àtìlẹ́yìn fún Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Ọ̀kan nínú wọn ni a ó sì máa pè ní ìlú ìparun.

19 Ní ọjọ́ náà pẹpẹ kan yóò wà fún Olúwa ní àárín gbùngbùn Ejibiti, àti ọ̀wọ́n kan fún Olúwa ní etí bodè rẹ̀. 20 Yóò sì jẹ́ ààmì àti ẹ̀rí sí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ilẹ̀ Ejibiti. Nígbà tí wọ́n bá ké pe Olúwa nítorí àwọn aninilára wọn, yóò rán olùgbàlà àti olùgbèjà kan sí wọn tí yóò sì gbà wọ́n sílẹ̀. 21 Báyìí ni Olúwa yóò sọ ara rẹ̀ di mí mọ̀ fún àwọn ará Ejibiti àti ní ọjọ́ náà ni wọn yóò gba Olúwa gbọ́. Wọn yóò sìn ín pẹ̀lú ẹbọ ọrẹ ìyẹ̀fun, wọn yóò jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa wọn yóò sì mú un ṣẹ. 22 Olúwa yóò fi àjàkálẹ̀-ààrùn kan bá Ejibiti jà; yóò bá wọn jà yóò sì tún wò wọ́n sàn. Wọn yóò yípadà sí Olúwa, Òun yóò sì gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wọn yóò sì wò wọ́n sàn.

23 Ní ọjọ́ náà òpópónà kan yóò wá láti Ejibiti lọ sí Asiria. Àwọn ará Asiria yóò lọ sí Ejibiti àti àwọn ará Ejibiti lọ sí Asiria. Àwọn ará Ejibiti àti ará Asiria yóò jọ́sìn papọ̀. 24 Ní ọjọ́ náà Israẹli yóò di ẹ̀kẹta pẹ̀lú Ejibiti àti Asiria, àní orísun ìbùkún ní ilẹ̀ ayé. 25 Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò bùkún wọn yóò wí pé, “Ìbùkún ni fún Ejibiti ènìyàn mi, Asiria iṣẹ́ ọwọ́ mi, àti Israẹli ìní mi.”

Àsọtẹ́lẹ̀ tó lòdì sí Ejibiti àti Kuṣi

20 Ní ọdún tí olórí ogun, tí Sagoni ọba Asiria rán an, wá sí Aṣdodu, ó kọlù ú ó sì kó o— ní àkókò náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa ti ẹnu Isaiah ọmọ Amosi jáde. Ó sọ fún un pé, “Mú aṣọ ọ̀fọ̀ kúrò ní ara rẹ kí o sì bọ́ sálúbàtà kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ.” Ó sì ṣe bẹ́ẹ̀, ó ń lọ káàkiri ní ìhòhò àti láì wọ bàtà.

Lẹ́yìn náà ni Olúwa wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí ìránṣẹ́ mi Isaiah ti lọ káàkiri ní ìhòhò àti láì wọ bàtà fún ọdún mẹ́ta, gẹ́gẹ́ bí ààmì àti àpẹẹrẹ sí Ejibiti àti Kuṣi, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni ọba Asiria yóò kó àwọn ìgbèkùn Ejibiti lọ ní ìhòhò àti láì wọ bàtà pẹ̀lú àwọn àtìpó Kuṣi, ọ̀dọ́ àti àgbà, pẹ̀lú ìbàdí ìhòhò—bí àbùkù Ejibiti. Gbogbo àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé Kuṣi tí wọ́n sì ń fi Ejibiti yangàn ni ẹ̀rù yóò dé bá tí a ó sì dójútì wọ́n. Ní ọjọ́ náà àwọn ènìyàn tí ó ń gbé ní etí Òkun yóò wí pé, ‘Wo ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí àwọn tí a ti gbẹ́kẹ̀lé, àwọn tí a sá tọ̀ lọ fún ìrànlọ́wọ́ àti ìtúsílẹ̀ láti ọwọ́ ọba Asiria! Báwo ni a ó ṣe sálà?’ ”

Àsọtẹ́lẹ̀ tó lòdì sí Babeli

21 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan aginjù lẹ́bàá Òkun:

Gẹ́gẹ́ bí ìjì líle ti í jà kọjá ní gúúsù,
    akógunjàlú kan wá láti aginjù,
    láti ilẹ̀ ìpayà.

Ìran tí a ń fojú ṣọ́nà fún ni a ti fihàn mí
    ọlọ̀tẹ̀ ti tu àṣírí, fọ́lé fọ́lé ti kẹ́rù.
Elamu kojú ìjà! Media ti tẹ̀gùn!
    Èmi yóò mú gbogbo Ìpayínkeke dópin,
ni ó búra.

Pẹ̀lú èyí, ìrora mu mi lára gírígírí,
    ìrora gbá mi mú, gẹ́gẹ́ bí i ti
obìnrin tí ń rọbí,
    Mo ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n nítorí ohun tí mo gbọ́,
    ọkàn mi pòruurù nípa ohun tí mo rí.
Ọkàn mí dàrú,
    ẹ̀rù mú jìnnìjìnnì bá mi,
ìmọ́lẹ̀ tí mo ti ń fẹ́ ẹ́ rí
    ti wá di ìpayà fún mi.

Wọ́n tẹ́ tábìlì,
    wọ́n tẹ́ ẹní àtẹ́ẹ̀ká,
wọ́n jẹ, wọ́n mu!
    Dìde nílẹ̀, ẹ̀yin ọmọ-aládé,
    ẹ fi òróró kún asà yín!

Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún mi:

“Lọ, kí o bojúwòde
    kí o sì wá sọ ohun tí ó rí.
Nígbà tí ó bá rí àwọn kẹ̀kẹ́ ogun
    àti àkójọpọ̀ àwọn ẹṣin,
àwọn tó ń gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́
    tàbí àwọn tí ó gun ìbákasẹ,
jẹ́ kí ó múra sílẹ̀,
    àní ìmúra gidigidi.”

Òun sì kígbe pé, kìnnìún kan;

“Láti ọjọ́ dé ọjọ́, olúwa mi, mo dúró lórí ilé ìṣọ́ ní ọ̀sán,
    a sì fi mí ìṣọ́ mi ní gbogbo òru.
Wò ó, ọkùnrin kan ni ó ń bọ̀ wá yìí
    nínú kẹ̀kẹ́ ogun
àti àkójọpọ̀ àwọn ẹṣin.
    Ó sì mú ìdáhùn padà wá:
‘Babeli ti ṣubú, ó ti ṣubú!
    Gbogbo àwọn ère òrìṣà rẹ̀
    ló fọ́nká sórí ilẹ̀!’ ”

10 Ẹ̀yin ènìyàn mi, tí a gún mọ́lẹ̀ ní ilẹ̀ ìpakà,
    mo sọ ohun tí mo ti gbọ́
láti ọ̀dọ̀ Olúwa àwọn ọmọ-ogun,
    láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Israẹli.

Àsọtẹ́lẹ̀ lòdì sí Edomu

11 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Dumahi:

Ẹnìkan ké sí mi láti Seiri wá
    “Alóre, kí ló kù nínú òru náà?”
12 Alóre náà dáhùn wí pé,
    “Òwúrọ̀ súnmọ́ tòsí, àti òru náà pẹ̀lú.
Bí ìwọ yóò bá béèrè, béèrè
    kí o sì tún padà wá.”

Àsọtẹ́lẹ̀ tó lòdì sí Arabia

13 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Arabia:

Ẹ̀yin ẹgbẹ́ èrò ti Dedani,
    tí ó pàgọ́ sínú igbó Arabia,
14 gbé omi wá fún àwọn tí òǹgbẹ ń gbẹ;
    ẹ̀yin tí ó ń gbé Tema,
    gbé oúnjẹ wá fún àwọn ìsáǹsá.
15 Wọ́n sá kúrò lọ́wọ́ idà,
    kúrò lọ́wọ́ idà tí a fàyọ,
kúrò lọ́wọ́ ọrun tí a fàyọ
    àti kúrò nínú ìgbóná ogun.

16 Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún mi: “Láàrín ọdún kan, gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀fà tí ó wà lábẹ́ ọgbà, í ti í kà á, gbogbo ògo Kedari yóò wá sí òpin. 17 Àwọn tafàtafà tí ó sálà, àwọn jagunjagun Kedari kò ní tó nǹkan.” Olúwa, Ọlọ́run Israẹli ni ó ti sọ̀rọ̀.

Àsọtẹ́lẹ̀ kan nípa Jerusalẹmu

22 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó jẹ mọ́ Àfonífojì ìran:

Kí ni ó ń dààmú yín báyìí,
    tí gbogbo yín fi gun orí òrùlé lọ?
Ìwọ ìlú tí ó kún fún rúkèrúdò,
    ìwọ ìlú àìtòrò òun rògbòdìyàn
a kò fi idà pa àwọn òkú rẹ,
    bẹ́ẹ̀ ni wọn kò kú ní ojú ogun.
Gbogbo àwọn olórí i yín ti jùmọ̀ sálọ;
    a ti kó wọn nígbèkùn láìlo ọfà.
Ẹ̀yin tí a mú ni a ti kó lẹ́rú papọ̀,
    lẹ́yìn tí ẹ ti sá nígbà tí ọ̀tá ṣì wà
    lọ́nà jíjìn réré.
Nítorí náà ni mo wí pé, “Yípadà kúrò lọ́dọ̀ mi:
    jẹ́ kí n sọkún kíkorò.
Má ṣe gbìyànjú àti tù mí nínú
    nítorí ìparun àwọn ènìyàn mi.”

Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ọjọ́ kan
    tí rúkèrúdò, rògbòdìyàn àti ẹ̀rùjẹ̀jẹ̀
    ní Àfonífojì ìmọ̀,
ọjọ́ tí a ń wó ògiri lulẹ̀
    àti sísun ẹkún lọ sí àwọn orí òkè.
Elamu mú apó-ọfà lọ́wọ́,
    pẹ̀lú àwọn agun-kẹ̀kẹ́-ogun àti àwọn ẹṣin,
    Kiri yọ àpáta rẹ̀ síta.
Àyànfẹ́ Àfonífojì rẹ kún fún kẹ̀kẹ́ ogun,
    àwọn ẹlẹ́ṣin ni a gbá jọ sí ẹnu-bodè ìlú.

Gbogbo ààbò Juda ni a ti ká kúrò.
Ìwọ sì gbójú sókè ní ọjọ́ náà
    sí àwọn ohun ìjà ní ààfin ti inú aginjù,
Ìwọ rí i pé ìlú u Dafidi
    ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ààyè níbi ààbò rẹ̀,
ìwọ ti tọ́jú omi
    sínú adágún ti ìsàlẹ̀.
10 Ìwọ ka àwọn ilé tí ó wà ní Jerusalẹmu
    ó sì wó ọ̀pọ̀lọpọ̀ ilé lulẹ̀ láti fún ògiri lágbára.
11 Ìwọ mọ agbemi sí àárín ògiri méjì
    fún omi inú adágún àtijọ́,
ṣùgbọ́n ìwọ kò wo ẹni tí ó ṣe é tẹ́lẹ̀
    tàbí kí o kọbi ara sí ẹni tí ó
    gbèrò rẹ̀ ní ìgbà pípẹ́ sẹ́yìn.

12 Olúwa, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun,
    pè ọ́ ní ọjọ́ náà
láti sọkún kí o sì pohùnréré,
    kí o tu irun rẹ dànù kí o sì
    da aṣọ ọ̀fọ̀ bora.
13 Ṣùgbọ́n Wò ó, ayọ̀ àti ayẹyẹ wà
    màlúù pípa àti àgùntàn pípa,
ẹran jíjẹ àti ọtí wáìnì mímu!
    “Jẹ́ kí a jẹ kí a mu,” ni ẹ̀yin wí,
    “nítorí pé lọ́la àwa ó kú!”

14 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti sọ èyí di mí mọ̀ létí ì mi: “Títí di ọjọ́ ikú yín a kò ní ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ yìí,” ni Olúwa wí, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun.

15 Èyí ni ohun tí Olúwa, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí:

Lọ, sọ fún ìríjú yìí pé,
    fún Ṣebna, ẹni tí ààfin wà ní ìkáwọ́ rẹ̀:
16 Kí ni ohun tí ò ń ṣe níhìn-ín-yìí àti pé
    ta ni ó sì fún ọ ní àṣẹ
láti gbẹ́ ibojì kan fún ara rẹ níhìn-ín-yìí,
    tí ó gbẹ́ ibojì ní ibi gíga
    tí ó sì gbẹ́ ibi ìsinmi rẹ nínú àpáta?

17 “Kíyèsára, Olúwa fẹ́ gbá ọ mú gírígírí
    kí ó sì jù ọ́ nù, Ìwọ ọkùnrin alágbára.
18 Òun yóò ká ọ rúgúdù bí i òkìtì
    yóò sì sọ ọ́ sí orílẹ̀-èdè ńlá kan.
Níbẹ̀ ni ìwọ yóò sì kú sí
    àti níbẹ̀ pẹ̀lú ni àwọn kẹ̀kẹ́ ogun
àràmọ̀ǹdà rẹ yóò wà—
    ìwọ di ìtìjú sí ilé ọ̀gá rẹ!
19 Èmi yóò yọ ọ́ kúrò ní ipò rẹ,
    a ó sì lé ọ kúrò ní ipò rẹ.

20 “Ní ọjọ́ náà. Èmi yóò ké sí ọmọ ọ̀dọ̀ mi, Eliakimu ọmọ Hilkiah. 21 Èmi yóò fi aṣọ rẹ wọ̀ ọ́, n ó sì so ẹ̀wọ̀n rẹ mọ́ ọn ní ọrùn, èmi ó sì gbé àṣẹ rẹ lé e lọ́wọ́. Òun yó sì jẹ́ baba fún gbogbo olùgbé e Jerusalẹmu àti fún ilé e Juda. 22 (C)Èmi yóò sì fi kọ́kọ́rọ́ ilé e Dafidi lé e ní èjìká; ohunkóhun tí ó bá ṣí, ẹnikẹ́ni kì yóò lè ti, ohunkóhun tí ó bá sì tì, ẹnikẹ́ni kì yóò le è ṣí. 23 Èmi yóò sì kàn mọ́lẹ̀ bí èèkàn tí ó dúró gírígírí ní ààyè e rẹ̀; òun yóò sì jẹ́ ibùjókòó ọlá fún ilé baba rẹ̀. 24 Gbogbo ògo ìdílé rẹ̀ ni wọn yóò sì fi kọ ní ọrùn: ìran rẹ̀ àti àrọ́mọdọ́mọ rẹ̀, gbogbo ohun èlò ife, títí dé orí ago ọtí.

25 “Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Èèkàn tí a kàn mọ́lẹ̀ gírígírí ní ààyè e rẹ̀ yóò yẹrí, yóò dẹ̀gbẹ́ yóò sì fẹ̀gbẹ́ lélẹ̀ àti ẹrù tí ó létéńté lórí i rẹ̀ ni a ó gé lulẹ̀.” Olúwa ni ó ti sọ ọ́.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)

Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.