Print Page Options
Previous Prev Day Next DayNext

Chronological

Read the Bible in the chronological order in which its stories and events occurred.
Duration: 365 days
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Version
Amosi 6-9

Ègbé ni fún àwọn tí ara rọ̀

Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ará rọ̀ ní Sioni
    àti ẹ̀yin tí ẹ wà ní abẹ́ ààbò ní òkè Samaria
àti ẹ̀yin olókìkí orílẹ̀-èdè
    tí ẹ̀yin ènìyàn Israẹli máa ń tọ̀ ọ́ wá
Ẹ lọ Kalne kí ẹ lọ wò ó
    kí ẹ sí tí ibẹ̀ lọ sí Hamati ìlú ńlá a nì.
    Kí ẹ sì tún sọ̀kalẹ̀ lọ Gati ní ilẹ̀ Filistini
Ǹjẹ́ wọ́n ha dára ju ìpínlẹ̀ yín méjèèjì lọ?
    Ǹjẹ́ a ha rí ilẹ̀ tó tóbi ju tiyín lọ bí?
Ẹ̀yin sún ọjọ́ ibi síwájú,
    ẹ sì mú ìjọba òǹrorò súnmọ́ tòsí
Ẹ̀yin sùn lé ibùsùn tí a fi eyín erin ṣe
    ẹ sì tẹ́ ara sílẹ̀ ni orí àwọn ibùsùn
ẹyin pa èyí tí o dára nínú àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn yín jẹ
    ẹ sì ń pa àwọn ọ̀dọ́ màlúù láàrín agbo wọn jẹ
Ẹ̀yin ń lo ohun èlò orin bí i Dafidi
    ẹ sì ń ṣe àwọn àpilẹ̀rọ àwọn ohun èlò orin
Ẹ̀yin mu wáìnì ẹ̀kún ọpọ́n kan
    àti ìkunra tí o dára jùlọ
    ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò káàánú ilé Josẹfu tí ó di ahoro
Nítorí náà, àwọn ni yóò lọ sí ìgbèkùn
    pẹ̀lú àwọn tí ó ti kó lọ sí ìgbèkùn
àsè àwọn tí ń ṣe àṣelékè ni a ó mú kúrò.

Olúwa Kórìíra Ìgbéraga Ọmọ Israẹli

Olúwa Olódùmarè ti búra fúnrarẹ̀, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun sì ti wí pé:

“Mo kórìíra ìgbéraga Jakọbu
    n kò sì ní inú dídùn sí odi alágbára rẹ̀
Èmi yóò sì fa ìlú náà lé wọn lọ́wọ́
    àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀.”

Bí Ọkùnrin mẹ́wàá bá ṣẹ́kù nínú ilé kan, àwọn náà yóò kú 10 Bí ẹbí tí ó yẹ kí ó gbé òkú wọn jáde fún sínsin bá wọlé, bí o ba sì béèrè pé ǹjẹ́ ẹnìkan wa tí ó fi ara pamọ́ níbẹ̀, “Ǹjẹ́ ẹnìkankan wà lọ́dọ̀ yín?” tí ó bá sì dáhùn wí pé, “Rárá,” nígbà náà ni yóò wí pé, “Pa ẹnu rẹ mọ́ àwa kò gbọdọ̀ dárúkọ Olúwa.”

11 Nítorí Olúwa tí pa àṣẹ náà,
    Òun yóò sì wó ilé ńlá náà lulẹ̀ túútúú
    Àti àwọn ilé kéékèèkéé sí wẹ́wẹ́.

12 Ǹjẹ́ ẹṣin a máa sáré lórí àpáta bí?
    Ǹjẹ́ ènìyàn a máa fi akọ màlúù kọ ilẹ̀ níbẹ̀?
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti yí òtítọ́ padà sí májèlé
    ẹ sì ti sọ èso òdodo di ìkorò.
13 Ẹ̀yin yọ̀ torí ìṣẹ́gun lórí Lo-Debari
    Ẹ̀yin sì wí pé, “Ṣé kì í ṣe agbára wa ni àwa fi gba Karnaimu?”

14 Nítorí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun wí pé,
    “Èmi yóò gbé orílẹ̀-èdè kan dìde sí ọ ìwọ Israẹli,
wọn yóò pọ́n yín lójú ní gbogbo ọ̀nà,
    láti Lebo-Hamati, títí dé pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah.”

Eṣú, iná àti ìwọ̀n okùn

Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè fihàn mí: Ó pèsè ọwọ́ eṣú lẹ́yìn ìgbà tí a kórè ìpín ọba, ní ìgbà ti èso ẹ̀ẹ̀kejì ń jáde bọ̀. Nígbà tí wọ́n jẹ koríko ilẹ̀ náà mọ́ féfé nígbà náà ni mo gbé ohùn mi sókè pé, “Olúwa Olódùmarè, mo bẹ̀ ọ́, dáríjì! Báwo ni Jakọbu yóò ha ṣe lè dìde? Òun kéré jọjọ!”

Olúwa ronúpìwàdà nípa èyí.

“Èyí kò ni ṣẹlẹ̀,” ni Olúwa wí.

Èyí ni ohun ti Olúwa Olódùmarè fihàn mí: Olúwa Olódùmarè ń pè fún ìdájọ́ pẹ̀lú iná; ó jó ọ̀gbun ńlá rún, ó sì jẹ ilẹ̀ run. Nígbà náà ni mo gbé ohùn mi sókè pé, “Olúwa Olódùmarè jọ̀wọ́ má ṣe ṣe é! Báwo ni Jakọbu yóò ha ṣe lè dìde? Òun kéré jọjọ!”

Olúwa ronúpìwàdà nípa èyí.

“Èyí náà kò ní ṣẹlẹ̀,” ni Olúwa Olódùmarè wí.

Èyí ni ohun tí ó fihàn mí: Olúwa dúró ní ẹ̀gbẹ́ odi ti a fi okùn ìwọ̀n mọ́, ti òun ti okùn ìwọ̀n tí ó rún ni ọwọ́ rẹ̀. Olúwa sì bi mi pé, “Amosi, kí ni ìwọ rí?”

Mo dáhùn pé, “Okùn ìwọ̀n.”

Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Wò ó, Èmí ń gbé okùn ìwọ̀n kalẹ̀ láàrín àwọn Israẹli ènìyàn mi; Èmi kì yóò sì tún kọjá lọ́dọ̀ wọn mọ́.

“Ibi gíga Isaaki wọ̀n-ọn-nì yóò sì di ahoro
    àti ibi mímọ Israẹli wọ̀n-ọn-nì yóò di ahoro.
    Èmi yóò sì fi idà dìde sí ilé Jeroboamu.”

Amosi àti Amasiah

10 Nígbà náà Amasiah àlùfáà Beteli ránṣẹ́ sí Jeroboamu ọba Israẹli, wí pé: “Amosi ti dìde láti dìtẹ̀ sí ọ ni àárín gbùngbùn Israẹli. Ilẹ̀ kò sì le gba gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ̀. 11 Nítorí èyí ni ohun ti Amosi ń sọ:

“ ‘Jeroboamu yóò ti ipa idà kú,
    Lóòtítọ́ Israẹli yóò lọ sí ìgbèkùn,
    jìnnà kúrò ní ilẹ̀ ìní wọn.’ ”

12 Nígbà náà ni Amasiah sọ fún Amosi pé, “Lọ jáde, ìwọ aríran! Padà sí ilẹ̀ àwọn Juda. Kí o máa jẹun rẹ níbẹ̀, kí o sì máa sọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ níbẹ̀. 13 Má ṣe sọtẹ́lẹ̀ mọ ni Beteli nítorí ibi mímọ́ ọba ni àti ibi tẹmpili ìjọba rẹ̀.”

14 Amosi dá Amasiah lóhùn pé, “Èmi kì í ṣe wòlíì tàbí àwọn ọmọ wòlíì, ṣùgbọ́n mo jẹ́ olùṣọ́-àgùntàn, mo sì ń ṣe ìtọ́jú igi ọ̀pọ̀tọ́ sikamore. 15 Ṣùgbọ́n Olúwa mu mi bí mo ti ń tọ́ agbo ẹran lẹ́yìn, ó sì wí fun mi pé, ‘Lọ sọtẹ́lẹ̀ fun àwọn Israẹli ènìyàn mi.’ 16 Nítorí náà nísinsin yìí, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. Ìwọ wí pé,

“ ‘Má ṣe sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí Israẹli
    Má sì ṣe wàásù sí ilé Isaaki.’

17 “Nítorí náà, èyí ni ohun ti Olúwa wí:

“ ‘Ìyàwó rẹ yóò di panṣágà ni ìlú,
    àwọn ọmọ ọkùnrin àti obìnrin rẹ yóò ti ipa idà ṣubú.
A ó fi okùn wọn ilẹ̀ rẹ, a ó sì pín in
    àti ìwọ pẹ̀lú yóò kú ni ilẹ̀ àìmọ́.
Israẹli yóò sì lọ sí ìgbèkùn,
    kúrò ní ilẹ̀ ìní wọn.’ ”

Agbọ̀n èso pípọ́n

Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè fihàn mi: agbọ̀n èso pípọ́n. Ó béèrè pé, “Amosi kí ni ìwọ rí.”

Mo sì dáhùn pé, “Agbọ̀n èso pípọ́n.”

Nígbà náà ni Olúwa wí fún mi pé, “Àsìkò náà pọ́n tó fún àwọn ènìyàn mi Israẹli; Èmi kì yóò dá wọn sí mọ́.”

Olúwa Olódùmarè wí pé, “Ní ọjọ́ náà, àwọn orin tẹmpili yóò yí padà sí ohùn réré ẹkún. Ọ̀pọ̀, àní ọ̀pọ̀ ara òkú ni yóò wà ni ibi gbogbo! Àní ni ìdákẹ́ jẹ́ẹ́!”

Ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yin tí ń tẹ aláìní lórí ba,
    tí ẹ sì ń sọ tálákà di ilẹ̀.

Tí ẹ ń wí pé,

“Nígbà wo ni oṣù tuntun yóò parí
    kí àwa bá à lè ta ọkà
kí ọjọ́ ìsinmi kí ó lè dópin
    kí àwa bá à le ta jéró?”
Kí a sì dín ìwọ̀n wa kù
    kí a gbéraga lórí iye tí a ó tà á
    kí a sì fi òṣùwọ̀n èké yàn wọ́n jẹ
Kí àwa lè fi fàdákà ra àwọn tálákà
    kí a sì fi bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì ra aláìní
    kí a sì ta jéró tí a kó mọ́ ilẹ̀.

Olúwa ti fi ìgbéraga Jakọbu búra pé: “Èmi kì yóò gbàgbé ọ̀kan nínú ohun tí wọ́n ṣe.

“Ǹjẹ́ ilẹ̀ náà kì yóò ha wárìrì fún èyí?
    Àwọn tí ń gbé inú rẹ̀ kì yóò ha ṣọ̀fọ̀?
Gbogbo ilẹ̀ yóò ru sókè bí omi Naili,
    yóò sì ru ú sókè pátápátá bí ìkún omi
    a ó sì tì í jáde, a ó sì tẹ̀ ẹ́ rì gẹ́gẹ́ bí odò Ejibiti.

“Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa Olódùmarè wí,

“Èmi yóò mú oòrùn wọ̀ ní ọ̀sán,
    Èmi yóò mú kí ayé ṣókùnkùn ní ọ̀sán gangan.
10 Èmí yóò yí àsè ẹ̀sìn yín padà sí ọ̀fọ̀,
    gbogbo orin yín ni èmi yóò sọ di ẹkún.
Èmi yóò mú kí gbogbo yín wọ aṣọ ọ̀fọ̀,
    kí a sì fá orí yín.
Èmi yóò mú kí ìgbà náà rí bí ìṣọ̀fọ̀ fún ọmọkùnrin
    kan ṣoṣo tí a bí àti òpin rẹ̀ bí ọjọ́ kíkorò.

11 “Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa Olódùmarè wí,
    “nígbà tí èmi yóò rán ìyàn sí ilẹ̀ náà,
kì í ṣe ìyàn oúnjẹ tàbí òǹgbẹ fún omi.
    Ṣùgbọ́n ìyàn gbígbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
12 Àwọn ènìyàn yóò rìn kiri láti Òkun dé Òkun
    wọn yóò sì máa rìn ká láti gúúsù sí àríwá,
wọn yóò máa wá ọ̀rọ̀ Olúwa
    ṣùgbọ́n wọn kì yóò rí i.

13 “Ní ọjọ́ náà

“àwọn arẹwà wúńdíá àti àwọn alágbára ọ̀dọ́mọkùnrin
    yóò dákú fún òǹgbẹ omi.
14 Àwọn tí ó fi ẹ̀ṣẹ̀ Samaria búra,
    tí wọ́n sì wí pé, ‘Bí ó ti dájú pé ọlọ́run rẹ ń bẹ láààyè, ìwọ Dani,’
    Bí ó ti dájú pè ọlọ́run rẹ ń bẹ láààyè, ìwọ Beerṣeba
Wọ́n yóò ṣubú,
    Wọn kì yóò si tún dìde mọ.”

A o pa Israẹli run

Mo rí Olúwa, ó dúró ní ẹ̀bá pẹpẹ, ó sì wí pé:

“Lu orí àwọn àtẹ́rígbà ìlẹ̀kùn
    kí àwọn òpó kí ó lè mì
fọ́ wọn sí orí àwọn gbogbo ènìyàn
    àwọn tí ó ṣẹ́kù ni èmi yóò fi idà pa,
Ẹni tí ó sálọ nínú wọn kí yóò sá gbé
    Ẹni ti ó sá àsálà nínú wọn kí yóò gbàlà.
Bí wọ́n tilẹ̀ wa ilẹ̀ lọ sí ipò òkú
    Láti ibẹ̀ ni ọwọ́ mi yóò ti tẹ̀ wọ́n
Bí wọ́n tilẹ̀ gun òkè ọ̀run lọ,
    láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti mú wọn sọ̀kalẹ̀.
Bí wọ́n tilẹ̀ fi ara wọn pamọ́ ni orí òkè Karmeli,
    èmi yóò wá wọn rí, Èmi yóò si mú wọn kúrò níbẹ̀.
Bí wọ́n tilẹ̀ fi ara pamọ́ fún mi sí ìsàlẹ̀ Òkun,
    láti ibẹ̀ ni Èmi yóò ti pàṣẹ fún ejò kí ó bù wọ́n ṣán.
Bí wọ́n tilẹ̀ lọ sí ìgbèkùn ní iwájú àwọn ọ̀tá wọn
    láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti pàṣẹ fún idà kí ó ṣá wọn pa.

“Èmi yóò sì tẹ ojú mi mọ́ wọn fún ìbí,
    kì í sì í ṣe fún rere.”

Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun,
    ẹni ti ó fi ọwọ́ kan ilẹ̀ náà tí ó sì yọ́, tí àwọn olùgbé inú rẹ̀ yóò sì ṣọ̀fọ̀;
gbogbo orílẹ̀-èdè yóò si ru sókè bí ríru odò Naili
    tiwọn yóò sì tẹ̀rì bí odò Ejibiti.
Òun ni ẹni tí ó kọ́ ìtẹ́ rẹ̀ nínú àwọn ọ̀run
    ti ó sì fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀ ní ilé ayé
Ẹni ti ó pe àwọn omi Òkun
    ti ó sì tú wọn jáde si orí ilé ayé
    Olúwa ni orúkọ rẹ̀.

“Àbá ẹ̀yin ọmọ Israẹli
    kò ha dàbí àwọn ọmọ Kuṣi sí mi?”
    ni Olúwa wí.
“Èmi kò ha ti mú Israẹli gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá
    àti àwọn Filistini láti ilẹ̀ Kafitori
    àti àwọn ará Aramu láti Kiri?

“Dájúdájú, ojú Olúwa Olódùmarè
    ń bẹ̀ lára ilẹ̀ ọba tó kún fún ẹ̀ṣẹ̀.
Èmi yóò pa á run kúrò lórí ilẹ̀
    Síbẹ̀ Èmi kò nípa ilé Jakọbu run pátápátá,”
    ni Olúwa wí.
“Nítorí Èmi yóò pàṣẹ,
    Èmi yóò sì mi ilé Israẹli
    ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè
bí a ti ń jọ nǹkan nínú ajọ̀
    tí hóró kín ń kín kì yóò bọ́ sórí ilẹ̀.
10 Gbogbo àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ láàrín àwọn ènìyàn mi
    ni yóò ti ipa idà kú
gbogbo àwọn ti ń wí pé,
    ‘Aburú kì yóò lé wa bá, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ká wa mọ́.’

Ìmúpadàbọ̀ Israẹli

11 (A)“Ní ọjọ́ náà ní
    Èmi yóò gbé àgọ́ Dafidi tí ó wó ró,
Èmi yóò dí odi rẹ̀ tí ó ya,
    Èmi yóò sì gbé ahoro rẹ̀ sókè,
    Èmi yóò sì kọ bí ti ọjọ́ ìgbàanì,
12 kí wọn le jogún ìyókù Edomu
    àti gbogbo àwọn kèfèrí, ti a ń pè nípa orúkọ mi,”
    ni Olúwa, ẹni tí yóò ṣe nǹkan wọ̀nyí wí.

13 (B)“Ọjọ́ náà ń bọ,” ni Olúwa wí,

“tí ẹni tí ń tulẹ̀ yóò lé ẹni tí ń kórè bá
    Tí ẹni tí ń fún èso àjàrà yóò lé ẹni tí ń gbìn bá
Àwọn òkè ńlá yóò sì kán ọtí wáìnì sílẹ̀
    Tí yóò sì sàn láti ara àwọn òkè kéékèèkéé.
14     Èmi yóò si tún mú ìgbèkùn Israẹli ènìyàn mi padà bọ̀.

“Wọn yóò sì kọ́ ahoro ìlú, wọn yóò sì máa gbé inú wọn
    Wọn yóò sì gbin ọgbà àjàrà, wọn yóò sì mu ọtí wáìnì wọn
    wọn yóò sì ṣe ọgbà pẹ̀lú, wọn yóò sì jẹ èso inú wọn
15 Èmi yóò gbin Israẹli sí orí ilẹ̀ rẹ̀.
    A kì yóò sì fà wọn tu mọ́ láéláé
    kúrò ni orí ilẹ̀ ti mo fi fún wọn,”

ni Olúwa Ọlọ́run rẹ wí.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)

Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.