Print Page Options
Previous Prev Day Next DayNext

Revised Common Lectionary (Semicontinuous)

Daily Bible readings that follow the church liturgical year, with sequential stories told across multiple weeks.
Duration: 1245 days
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Version
Saamu 94

94 Olúwa Ọlọ́run ẹni tí ń gbẹ̀san,
    Ọlọ́run ẹni tí ń gbẹ̀san.
Gbé ara rẹ sókè, ìwọ onídàájọ́ ayé;
    san ẹ̀san fún agbéraga
    ohun tí ó yẹ wọ́n.
Báwo ní yóò ti pẹ́ tó,
    Olúwa
tí àwọn ẹni búburú
    yóò kọ orin ayọ̀?

Wọ́n ń sọ̀rọ̀ ìgbéraga jáde;
    gbogbo àwọn olùṣe búburú
kún fún ìṣògo.
Wọ́n fọ́ àwọn ènìyàn rẹ túútúú, Olúwa:
    wọ́n pọ́n ilẹ̀ ìní rẹ̀ lójú.
Wọ́n pa àwọn opó àti àlejò,
    wọ́n sì pa àwọn ọmọ aláìní baba,
Wọ́n sọ pé, “Olúwa kò rí i;
    Ọlọ́run Jakọbu kò sì kíyèsi i.”

Kíyèsi i, ẹ̀yin aláìlóye nínú àwọn ènìyàn
    ẹ̀yin aṣiwèrè, nígbà wo ni ẹ̀yin yóò lóye?
Ẹni tí ó gbin etí, ó lè ṣe aláìgbọ́ bí?
    Ẹni tí ó dá ojú?
Ó ha lè ṣe aláìríran bí?
10 Ẹni tí ń bá orílẹ̀-èdè wí, ṣé kò lè tọ́ ni ṣọ́nà bí?
    Ẹni tí ń kọ́ ènìyàn ha lè ṣàìní ìmọ̀ bí?
11 (A)Olúwa mọ èrò inú ènìyàn;
    ó mọ̀ pé asán ni wọ́n.

12 Ìbùkún ni fún ènìyàn náà tí
    ìwọ bá wí, Olúwa,
ẹni tí ìwọ kọ́ nínú òfin rẹ;
13 Ìwọ gbà á kúrò nínú ọjọ́ ibi,
    títí a ó fi wa ihò sílẹ̀ fún ẹni búburú.
14 Nítorí Olúwa kò ní kọ àwọn ènìyàn rẹ̀ sílẹ̀;
Òun kò sì ní kọ ilẹ̀ ìní rẹ̀ sílẹ̀.
15 Ìdájọ́ yóò padà sí òdodo,
    àti gbogbo àwọn ọlọ́kàn
    dídúró ṣinṣin yóò tẹ̀lé e lẹ́yìn.

16 Ta ni yóò dìde fún mi
    sí àwọn olùṣe búburú?
    Tàbí ta ni yóò dìde sí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ fún mi?
17 Bí kò ṣe pé Olúwa fún mi ní ìrànlọ́wọ́,
    èmi fẹ́rẹ̀ máa gbé ní ilẹ̀ tí ó dákẹ́
18 Nígbà tí mo sọ pé “Ẹsẹ̀ mi ń yọ̀”,
    Olúwa, ìfẹ́ rẹ̀ ni ó tì mí lẹ́yìn.
19 Nígbà tí àníyàn ńlá wà nínú mi,
    ìtùnú rẹ̀ mú ayọ̀ sí ọkàn mi.

20 Ìjọba ìbàjẹ́ ha lè kẹ́gbẹ́ pẹ̀lú rẹ
    ẹni tí ń fi òfin dì mọ́ ìwà ìkà?
21 Wọ́n kó ara wọn jọ sí olódodo
    wọ́n sì ń dá àwọn aláìṣẹ̀ lẹ́bi sí ikú.
22 Ṣùgbọ́n, Olúwa ti di odi alágbára mi,
    àti Ọlọ́run mi ni àpáta nínú ẹni
    tí mo ti ń gba ààbò.
23 Òun yóò san ẹ̀san ibi wọn fún wọn
    yóò sì pa wọ́n run nítorí búburú wọn
    Olúwa Ọlọ́run wa yóò pa wọ́n run.

Jeremiah 5:1-17

Kò sí ọ̀kan tí o jẹ́ olóòtítọ́

“Lọ sókè àti sódò àwọn òpópó Jerusalẹmu
    wò yíká, kí o sì mọ̀,
kí o sì wá kiri
    Bí o bá le è rí ẹnìkan,
tí ó jẹ́ olóòtítọ́ àti olódodo,
    n ó dáríjì ìlú yìí.
Bí wọ́n tilẹ̀ wí pé, ‘Bí Olúwa ti ń bẹ,’
    síbẹ̀ wọ́n búra èké.”

Olúwa, ojú rẹ kò ha wà lára òtítọ́
    Ìwọ lù wọ́n, kò dùn wọ́n.
Ìwọ bá wọn wí, wọ́n kọ̀ láti yípadà.
    Wọ́n mú ojú wọn le ju òkúta lọ,
    wọ́n sì kọ̀ láti yípadà.
Èmi sì rò pé, “Tálákà ni àwọn yìí;
    wọn jẹ́ aṣiwèrè,
nítorí pé wọn kò mọ ọ̀nà Olúwa,
    àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.
Nítorí náà, èmi yóò tọ àwọn adarí lọ,
    n ó sì bá wọn sọ̀rọ̀;
ó dájú wí pé wọ́n mọ ọ̀nà Olúwa
    àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.”
Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìfìmọ̀ṣọ̀kan, wọ́n ti ba àjàgà jẹ́,
    wọ́n sì ti já ìdè.
Nítorí náà, kìnnìún láti inú igbó yóò kọlù wọ́n,
    ìkookò aginjù yóò sì pa wọ́n run,
ẹkùn yóò máa ṣe ibùba sí ẹ̀bá ìlú yín
    ẹnikẹ́ni tí ó bá jáde ni yóò fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ,
nítorí àìgbọ́ràn yín pọ,
    ìpadàsẹ́yìn wọn sì pọ̀.

“Kí ni ṣe tí èmi ó ṣe dáríjì ọ́?
    Àwọn ọmọ rẹ ti kọ̀ mí sílẹ̀
àti pé wọ́n ti fi ọlọ́run tí kì í ṣe Ọlọ́run búra.
    Mo pèsè fún gbogbo àìní wọn,
síbẹ̀ wọ́n tún ń ṣe panṣágà
    wọ́n sì kórajọ sí ilé àwọn alágbèrè.
Wọ́n jẹ́ akọ ẹṣin tí a bọ́ yó,
    tí ó lágbára, wọ́n sì ń sọkún sí aya arákùnrin wọn.
Èmi kì yóò ha ṣe ìbẹ̀wò nítorí nǹkan wọ̀nyí?”
    ni Olúwa wí.
    “Èmi kì yóò wá gba ẹ̀san fúnra mi
    lára irú orílẹ̀-èdè bí èyí bí?

10 “Lọ sí ọgbà àjàrà rẹ̀, kí ẹ sì pa wọ́n run,
    ẹ má ṣe pa wọ́n run pátápátá.
Ya ẹ̀ka rẹ̀ kúrò,
    nítorí àwọn ènìyàn wọ̀nyí kì í ṣe ti Olúwa.
11 Ilé Israẹli àti ilé Juda
    ti jẹ́ aláìṣòdodo sí mi,”
    ni Olúwa wí.

12 Wọ́n ti pa irọ́ mọ́ Olúwa;
    wọ́n wí pé, “Òun kì yóò ṣe ohun kan!
Ibi kan kì yóò sì tọ̀ wá wá;
    àwa kì yóò sì rí idà tàbí ìyàn.
13 Àwọn wòlíì wá dàbí afẹ́fẹ́,
    ọ̀rọ̀ kò sí nínú wọn.
    Nítorí náà, jẹ́ kí ohun tí wọ́n bá sọ ṣẹlẹ̀ sí wọn.”

14 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Alágbára wí:

“Nítorí tí àwọn ènìyàn ti sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí;
    Èmi yóò sọ ọ̀rọ̀ mi lẹ́nu wọn di iná,
    àti àwọn ènìyàn wọ̀nyí di igi tí yóò jórun.
15 Háà, ẹ̀yin ilé Israẹli,” ni Olúwa wí,
    “Èmi yóò mú kí orílẹ̀-èdè láti ọ̀nà jíjìn dìde sí i yín
Orílẹ̀-èdè àtijọ́ àti alágbára nì
    àwọn ènìyàn tí ìwọ kò mọ èdè rẹ̀,
    tí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kò sì yé ọ.
16 Apó-ọfà rẹ sì dàbí isà òkú tí a ṣí
    gbogbo wọn sì jẹ́ akọni ènìyàn.
17 Wọn yóò jẹ ìkórè rẹ àti oúnjẹ rẹ,
    àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin,
wọn yóò sì jẹ agbo àti ẹran rẹ,
    wọn yóò jẹ àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ.
Pẹ̀lú idà ni wọn ó run
    ìlú tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé.

1 Timotiu 1:18-20

18 Àṣẹ yìí ni mo pa fún ọ, Timotiu ọmọ mi, gẹ́gẹ́ bí ìsọtẹ́lẹ̀ wọ̀nyí tó ó ti ṣáájú nípa rẹ̀, pé nípasẹ̀ wọ́n kí ìwọ lè máa ja ìjà rere; 19 Máa ní ìgbàgbọ́ àti ẹ̀rí ọkàn rere. Èyí ti àwọn mìíràn ti mú kúrò lọ́dọ̀ wọn tí wọ́n sì rí ọkàn ìgbàgbọ́ wọn; 20 Nínú àwọn ẹni tí Himeneu àti Aleksanderu wà; àwọn tí mo ti fi lé Satani lọ́wọ́, kí a lè kọ́ wọn kí wọ́n má sọ̀rọ̀-òdì mọ́.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)

Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.