Print Page Options
Previous Prev Day Next DayNext

Revised Common Lectionary (Semicontinuous)

Daily Bible readings that follow the church liturgical year, with sequential stories told across multiple weeks.
Duration: 1245 days
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Version
Saamu 7

Ṣiggaioni ti Dafidi, èyí tí ó kọ sí Olúwa nípa Kuṣi, ará Benjamini.

Olúwa Ọlọ́run mi, ààbò mi wà nínú rẹ;
    gba mí là kí o sì tú mi sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn tó ń lé mi,
kí wọn ó má ba à fa ọkàn mi ya gẹ́gẹ́ bí kìnnìún,
    wọ́n á ya á pẹ́rẹpẹ̀rẹ láìsí ẹni tí yóò gbà mí.

Olúwa Ọlọ́run mi, tí èmi bá ṣe èyí
    tí ẹ̀bi sì wà ní ọwọ́ mi
Bí èmi bá ṣe ibi sí ẹni tí ń wá àlàáfíà pẹ̀lú mi,
    tí mo ja ọ̀tá mi lólè láìnídìí:
Nígbà náà, jẹ́ kí ọ̀tá mi lé mi kí wọn sì mú mi;
    jẹ́ kí òun kí ó tẹ ọkàn mi mọ́lẹ̀
    kí wọn sì mú mi sùn nínú eruku. Sela.

Dìde, Olúwa, nínú ìbínú rẹ;
    dìde lòdì sí ìrunú àwọn ọ̀tá mi.
    Jí, Ọlọ́run mi; kéde òdodo.
Kí ìpéjọ àwọn ènìyàn yíká.
    Jọba lórí wọn láti òkè wá;
    Jẹ́ kí Olúwa ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn.
Ṣe ìdájọ́ mi, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí òdodo mi,
    gẹ́gẹ́ bí ìwà òtítọ́, ẹni gíga jùlọ.
(A)Ọlọ́run Olódodo,
    Ẹni tí ó ń wo inú àti ọkàn,
tí ó ń mú òpin sí ìwà ipá ẹni búburú
    tí ó sì ń pa àwọn olódodo mọ́.

10 Ààbò mi ń bẹ lọ́dọ̀ Ọlọ́run,
    ẹni tí ń ṣe ìgbàlà òtítọ́ ní àyà.
11 Ọlọ́run ni onídàájọ́ òtítọ́,
    Ọlọ́run tí ń sọ ìrunú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́.
12 Bí kò bá yípadà,
    Òun yóò pọ́n idà rẹ̀ mú;
    ó ti fa ọrun rẹ̀ le ná, ó ti múra rẹ̀ sílẹ̀.
13 Ó ti pèsè ohun ìjà ikú sílẹ̀;
    ó ti pèsè ọfà iná sílẹ̀.

14 Ẹni tí ó lóyún ohun búburú,
    tí ó sì lóyún wàhálà, ó bí èké jáde.
15 Ẹni tí ó gbẹ́ ọ̀fìn, tí ó kó o jáde
    jì sí kòtò tí ó gbẹ́ sílẹ̀.
16 Wàhálà tí ó fà padà sórí rẹ̀;
    Ìwà ipá rẹ̀ padà sórí ara rẹ̀.

17 Èmi ó fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí òdodo rẹ̀,
    Èmi ó kọrin ìyìn sí Olúwa Ọ̀gá-ògo jùlọ.

Amosi 3:9-4:5

Ẹ kéde ní ààfin Aṣdodu
    àti ní ààfin ní ilẹ̀ Ejibiti.
“Ẹ kó ara yín jọ sí orí òkè ńlá Samaria;
    Kí ẹ sì wo ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ńlá láàrín rẹ̀
    àti ìnilára láàrín àwọn ènìyàn rẹ.”

10 “Wọn kò mọ bí wọ́n ṣe ń ṣe rere,” ni Olúwa wí,
    “àwọn ẹni tí ó gba àwọn ìwà ipá àti olè sí ààfin rẹ̀.”

11 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí:

“Àwọn ọ̀tá yóò pa ilẹ̀ náà run;
    yóò wó ibi gíga yín palẹ̀
    a ó sì ba ààfin rẹ̀ jẹ́.”

12 Èyí ni ohun tí Olúwa wí:

“Bí olusọ-àgùntan ti ń gbà itan méjì
    kúrò ní ẹnu kìnnìún tàbí ẹ̀là etí kan
    bẹ́ẹ̀ ni a ó mú àwọn ọmọ Israẹli,
tí ń gbé Samaria kúrò
    ní igun ibùsùn wọn
    ní orí àga ìrọ̀gbọ̀kú wọn ní Damasku.”

13 “Gbọ́ èyí kí o sì jẹ́rìí nípa ilé Jakọbu,” ni Olúwa wí, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun.

14 “Ní ọjọ́ tí mo fìyà jẹ Israẹli lórí ẹ̀ṣẹ̀ wọn,
    Èmi yóò pa pẹpẹ Beteli run;
ìwo pẹpẹ ni a ó ké kúrò
    yóò sì wó lulẹ̀.
15 Èmi yóò wó ilé òtútù
    lulẹ̀ pẹ̀lú ilé ooru;
ilé tí a fi eyín erin ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ yóò ṣègbé
    a ó sì pa ilé ńlá náà run,”
    ni Olúwa wí.

Israẹli kò yípadà sí Ọlọ́run

Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí, ẹ̀yin màlúù Baṣani lórí òkè Samaria,
    ẹ̀yin obìnrin tí ó ń ni tálákà lára,
    tí ó ń tẹ aláìní mọ́lẹ̀, tí ó wí fún ọkọ rẹ̀, “Gbé wá kí a sì mu!”
Olúwa Olódùmarè ti fi ìwà mímọ́ rẹ̀ búra:
    “Àkókò náà yóò dé nítòótọ́
nígbà tí a ó fi ìwọ̀ mú un yín lọ,
    ẹni tí ó kẹ́yìn pẹ̀lú ìwọ̀ ẹja.
Ẹni kọ̀ọ̀kan yín yóò jáde lọ
    gba àárín odi yíya
    a ó sì lé e yín sí Harmoni,”
    ni Olúwa wí.
“Ẹ lọ sí Beteli láti dẹ́ṣẹ̀;
    ẹ lọ sí Gilgali kí ẹ sì dẹ́ṣẹ̀ sí i.
Ẹ mú ẹbọ sísun yín láràárọ̀ wá,
    ìdámẹ́wàá yín ní ọdọọdún mẹ́ta.
Kí ẹ mú ọ̀rẹ́ ìdúpẹ́ ìyẹ̀fun ìwúkàrà ti a sun
    kí ẹ sì mú ọrẹ àtinúwá
lọ fi wọ́n yangàn, ẹ̀yin ènìyàn Israẹli,
    nítorí èyí ni ẹ fẹ́ láti ṣe,”
    ni Olúwa Olódùmarè wí.

Jakọbu 2:1-7

Ojúsàájú jẹ́ èèwọ̀

Ẹ̀yin ará mi, gẹ́gẹ́ bí onígbàgbọ́ nínú ògo Olúwa wá Jesu Kristi, ẹ máa ṣe ojúsàájú ẹnikẹ́ni. Nítorí bí ọkùnrin kan bá wá sí ìpéjọpọ̀ yín, pẹ̀lú òrùka wúrà àti aṣọ dáradára, tí tálákà kan sì wá pẹ̀lú nínú aṣọ èérí; tí ẹ̀yin sì bu ọlá fún ẹni tí ó wọ aṣọ dáradára tí ẹ sì wí pé, “Ìwọ jókòó níhìn-ín yìí ní ibi dáradára” tí ẹ sì wí fún tálákà náà pé, “Ìwọ dúró níbẹ̀” tàbí “jókòó níhìn-ín lábẹ́ àpótí ìtìsẹ̀ mi,” ẹyin kò ha ń dá ara yín sí méjì nínú ara yín, ẹ̀yin kò sì di onídàájọ́ tí ó ní èrò búburú bí?

Ẹ fi etí sílẹ̀, ẹ̀yin ará mi olùfẹ́: Ọlọ́run kò ha ti yan àwọn tálákà ayé yìí láti jẹ́ ọlọ́rọ̀ nínú ìgbàgbọ́, àti ajogún ìjọba náà, tí ó ti ṣe ìlérí fún àwọn tí ó fẹ́ ẹ? Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti bu tálákà kù. Àwọn ọlọ́rọ̀ kò ha ń pọ́n yin lójú bí; wọn kò ha sì ń wọ́ yín lọ sílé ẹjọ́? Wọn kò ha ń sọ ọ̀rọ̀-òdì sí orúkọ rere nì tí a fi ń pè yín bí?

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)

Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.