M’Cheyne Bible Reading Plan
Samuẹli fi Saulu bú
13 Saulu sì jẹ́ ọmọ ọgbọ̀n ọdún nígbà tí ó jẹ ọba, ó sì jẹ ọba lórí Israẹli ní ọdún méjìlélógójì.
2 Saulu yan ẹgbẹ̀ẹ́dógún (3,000) ọkùnrin ní Israẹli, ẹgbẹ̀rún méjì (2,000) sì wà lọ́dọ̀ rẹ̀ ní Mikmasi àti ní ìlú òkè Beteli ẹgbẹ̀rún kan (1,000) sì wà lọ́dọ̀ Jonatani ní Gibeah ti Benjamini. Àwọn ọkùnrin tókù ni ó rán padà sí ilé e wọn.
3 Jonatani sì kọlu ẹgbẹ́ ogun àwọn Filistini ní Gibeah, Filistini sì gbọ́ èyí. Nígbà náà ni Saulu fọn ìpè yí gbogbo ilẹ̀ náà ká, ó sì wí pé, “Jẹ́ kí àwọn Heberu gbọ́!” 4 Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo Israẹli sì gbọ́ ìròyìn pé, “Saulu ti kọlu ẹgbẹ́ ogun àwọn Filistini, Israẹli sì di òórùn búburú fún àwọn Filistini.” Àwọn ènìyàn náà sì péjọ láti darapọ̀ mọ́ Saulu ní Gilgali.
5 Àwọn Filistini kó ara wọn jọ pọ̀ láti bá Israẹli jà, pẹ̀lú ẹgbàá-mẹ́dógún kẹ̀kẹ́, (3,000) ẹgbẹ̀ta (6,000) ọkùnrin ẹlẹ́ṣin, àwọn ológun sì pọ̀ bí yanrìn etí Òkun. Wọ́n sì gòkè lọ, wọ́n dó ní Mikmasi ní ìhà ilẹ̀ oòrùn Beti-Afeni. 6 Nígbà tí àwọn ọkùnrin Israẹli sì rí i pé àwọn wà nínú ìpọ́njú àti pé àwọn ológun wọn wà nínú ìhámọ́, wọ́n fi ara pamọ́ nínú ihò àti nínú igbó láàrín àpáta, nínú ọ̀fìn, àti nínú kànga gbígbẹ. 7 Àwọn Heberu mìíràn tilẹ̀ kọjá a Jordani sí ilẹ̀ Gadi àti Gileadi.
Saulu wà ní Gilgali síbẹ̀, gbogbo àwọn ọ̀wọ́ ogun tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ sì ń wárìrì fún ìbẹ̀rù. 8 Ó sì dúró di ọjọ́ méje, àkókò tí Samuẹli dá; ṣùgbọ́n Samuẹli kò wá sí Gilgali, àwọn ènìyàn Saulu sì bẹ̀rẹ̀ sí ní túká. 9 Saulu sì wí pé, “Ẹ mú ẹbọ sísun àti ẹbọ ìrẹ́pọ̀ wá fún mi.” Saulu sì rú ẹbọ sísun náà. 10 Bí ó sì ti ń parí rírú ẹbọ sísun náà, Samuẹli sì dé, Saulu sì jáde láti lọ kí i.
11 Samuẹli sì wí pé, “Kí ni ìwọ ṣe yìí.”
Saulu sì dáhùn pé, “Nígbà tí mo rí pé àwọn ènìyàn náà ń túká, àti tí ìwọ kò sì wá ní àkókò ọjọ́ tí ìwọ dá, tí àwọn Filistini sì kó ara wọ́n jọ ní Mikmasi, 12 mo rò pé, ‘Àwọn Filistini yóò sọ̀kalẹ̀ tọ̀ mí wá ní Gilgali nísinsin yìí, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò ì tí ì wá ojúrere Olúwa.’ Báyìí ni mo mú ara mi ní ipá láti rú ẹbọ sísun náà.”
13 Samuẹli sì wí fún un pé, “Ìwọ hu ìwà aṣiwèrè, ìwọ kò sì pa òfin tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ mọ́; bí o kò bá ṣe bẹ́ẹ̀, òun ìbá fi ìdí ìjọba rẹ kalẹ̀ lórí Israẹli láéláé. 14 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ìjọba rẹ kì yóò dúró pẹ́, Olúwa ti wá ọkùnrin tí ó wù ú ní ọkàn rẹ̀ fún ara rẹ̀, ó sì ti yàn án láti ṣe olórí fún àwọn ènìyàn rẹ̀, nítorí pé ìwọ kò pa òfin Olúwa mọ́.”
15 Nígbà náà ni Samuẹli kúrò ní Gilgali, ó sì gòkè lọ sí Gibeah ti Benjamini, Saulu sì ka àwọn ènìyàn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀, wọ́n sì jẹ́ ẹgbẹ̀ta.
Israẹli láìní ohun ìjà
16 Saulu àti ọmọ rẹ̀ Jonatani àti àwọn ènìyàn tí ó wà pẹ̀lú wọn dúró ní Gibeah ti Benjamini, nígbà tí àwọn Filistini dó ní Mikmasi. 17 Ẹgbẹ́ àwọn onísùmọ̀mí mẹ́ta jáde lọ ní àgọ́ àwọn Filistini ní ọnà ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀. Ẹgbẹ́ kan gba ọ̀nà ti Ofira ní agbègbè ìlú Ṣuali, 18 òmíràn gba ọ̀nà Beti-Horoni, ẹ̀kẹta sí ìhà ibodè tí ó kọjú sí Àfonífojì Ṣeboimu tí ó kọjú sí ijù.
19 A kò sì rí alágbẹ̀dẹ kan ní gbogbo ilẹ̀ Israẹli, nítorí tí àwọn Filistini wí pé, “Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ àwọn Heberu yóò rọ idà tàbí ọ̀kọ̀!” 20 Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo Israẹli tọ àwọn Filistini lọ láti pọ́n dòjé wọn, ọ̀kọ̀, àáké àti ọ̀ṣọ́ wọn. 21 Iye tí wọ́n fi pọ́n dòjé àti ọ̀kọ̀ jẹ́ ọwọ́ méjì nínú ìdámẹ́ta ṣékélì, àti ìdámẹ́ta ṣékélì fún pípọ́n òòyà-irin tí ilẹ̀, àáké àti irin ọ̀pá olùṣọ́ màlúù.
Jonatani kọlu àwọn ará Filistini
22 Bẹ́ẹ̀ ni ọjọ́ ìjà ẹnìkankan nínú àwọn ọmọ-ogun tí ó wà pẹ̀lú Saulu àti Jonatani kò sì ní idà, tàbí ọ̀kọ̀ ní ọwọ́; àfi Saulu àti ọmọ rẹ̀ Jonatani ni wọ́n ni wọ́n.
23 Àwọn ẹgbẹ́ ogun Filistini sì ti jáde lọ sí ìkọjá Mikmasi.
Àwọn Israẹli tó ṣẹ́kù
11 (A)Ǹjẹ́ mo ní: Ọlọ́run ha ta àwọn ènìyàn rẹ̀ nù bí? Kí a má ri. Nítorí Israẹli ni èmi pẹ̀lú, láti inú irú-ọmọ Abrahamu, ni ẹ̀yà Benjamini. 2 (B)Ọlọ́run kò ta àwọn ènìyàn rẹ̀ nù ti ó ti mọ̀ tẹ́lẹ̀. Tàbí ẹ̀yin kò mọ bí ìwé mímọ́ ti wí ní ti Elijah? Bí ó ti ń bẹ̀bẹ̀ lọ́dọ̀ Ọlọ́run fún Israẹli, wí pé: 3 “Olúwa, wọ́n ti pa àwọn wòlíì rẹ, wọn sì ti wó àwọn pẹpẹ rẹ lulẹ̀; èmi nìkan ṣoṣo ni ó sì kù, wọ́n sì ń wá ẹ̀mí mi.” 4 (C)Ṣùgbọ́n ìdáhùn wo ni Ọlọ́run fi fún un? “Mo ti ṣẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin ènìyàn kù sílẹ̀ fún ara mi, àwọn tí kò tẹ eékún ba fún Baali.” 5 (D)Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ sì ni, ní àkókò yìí àṣẹ́kù àwọn ènìyàn kan wà nípa ìyànfẹ́ ti oore-ọ̀fẹ́. 6 (E)Bí ó bá sì ṣe pé nípa ti oore-ọ̀fẹ́ ni, ǹjẹ́ kì í ṣe ti iṣẹ́ mọ́; bí bẹ́ẹ̀ kọ́ oore-ọ̀fẹ́ kì yóò jẹ́ oore-ọ̀fẹ́ mọ́. Ṣùgbọ́n bí ó ṣe pé nípa ti iṣẹ́ ni, ǹjẹ́ kì í ṣe ti oore-ọ̀fẹ́ mọ́; bí bẹ́ẹ̀ kọ́, iṣẹ́ kì í ṣe iṣẹ́ mọ́.
7 (F)Kí ha ni? Ohun tí Israẹli ń wá kiri, òun náà ni kò rí; ṣùgbọ́n àwọn ẹni àyànfẹ́ ti rí i, a sì sé àyà àwọn ìyókù le. 8 (G)Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé:
“Ọlọ́run ti fún wọn ní ẹ̀mí oorun,
àwọn ojú tí kò le ríran
àti àwọn etí tí kò le gbọ́rọ̀,
títí ó fi di òní olónìí yìí.”
9 (H)Dafidi sì wí pé:
“Jẹ́ kí tábìlì wọn kí ó di ìdẹ̀kùn àti tàkúté,
ohun ìkọ̀sẹ̀ àti ẹ̀san fún wọn;
10 Jẹ́ kí ojú wọn ṣókùnkùn, kí wọn kí ó má le ríran,
Kí wọn kí ó sì tẹ ẹ̀yìn wọn ba nígbà gbogbo.”
Ìran aláìkọlà pín nínú ìgbàlà àwọn ọmọ Israẹli
11 (I)Ǹjẹ́ mo ní, wọ́n ha kọsẹ̀ kí wọn kí ó lè ṣubú? Kí a má ri i, ṣùgbọ́n nípa ìṣubú wọn, ìgbàlà dé ọ̀dọ̀ àwọn Kèfèrí, láti mú Israẹli jowú. 12 Ṣùgbọ́n bí ìṣubú wọn bá di ọrọ̀ ayé, àti bí ìfàsẹ́yìn wọn bá di ọrọ̀ àwọn Kèfèrí; mélòó mélòó ni kíkún ọrọ̀ wọn?
13 (J)Ẹ̀yin tí i ṣe Kèfèrí ni èmi sá à ń bá sọ̀rọ̀, níwọ̀n bí èmi ti jẹ́ aposteli àwọn Kèfèrí, mo gbé oyè mi ga 14 (K)bí ó le ṣe kí èmi kí ó lè mú àwọn ará mi jowú, àti kí èmi kí ó lè gba díẹ̀ là nínú wọn. 15 (L)Nítorí bí títanù wọn bá jẹ́ ìlàjà ayé, gbígbà wọn yóò ha ti rí, bí kò sí ìyè kúrò nínú òkú? 16 Ǹjẹ́ bí àkọ́so bá jẹ́ mímọ́, bẹ́ẹ̀ ni àkópọ̀ yóò jẹ́ mímọ́; bí gbòǹgbò bá sì jẹ́ mímọ́, bẹ́ẹ̀ sì ni àwọn ẹ̀ka rẹ̀ náà.
17 Ṣùgbọ́n bí a bá ya nínú àwọn ẹ̀ka kúrò, tí a sì lọ́ ìwọ, tí í ṣe igi òróró igbó sára wọn, tí ìwọ sì ń bá wọn pín nínú gbòǹgbò àti ọ̀rá igi olifi náà, 18 Má ṣe ṣe féfé sí àwọn ẹ̀ka igi náà. Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá ṣe féfé, ìwọ kọ́ ni ó rù gbòǹgbò, ṣùgbọ́n gbòǹgbò ni ó rù ìwọ. 19 Ǹjẹ́ ìwọ ó wí pé, “A ti fa àwọn ẹ̀ka náà ya, nítorí kí a lè lọ́ mi sínú rẹ̀.” 20 (M)Ó dára; nítorí àìgbàgbọ́ ni a ṣe fà wọn ya kúrò, ìwọ sì dúró nípa ìgbàgbọ́ rẹ. Má ṣe gbé ara rẹ ga, ṣùgbọ́n bẹ̀rù. 21 Nítorí bí Ọlọ́run kò bá dá ẹ̀ka-ìyẹ́ka sí, kíyèsára kí ó má ṣe ṣe àìdá ìwọ náà sí.
22 Nítorí náà wo oore àti ìkáàánú Ọlọ́run; lórí àwọn tí ó ṣubú, ìkáàánú; ṣùgbọ́n lórí ìwọ, oore, bi ìwọ bá dúró nínú oore rẹ̀; kí a má bá ké ìwọ náà kúrò. 23 Àti àwọn pẹ̀lú, bí wọn kò bá jókòó sínú àìgbàgbọ́, a ó lọ́ wọn sínú rẹ̀, nítorí Ọlọ́run le tún wọn lọ́ sínú rẹ̀. 24 Nítorí bí a bá ti ké ìwọ kúrò lára igi òróró igbó nípa ẹ̀dá rẹ̀, tí a sì lọ́ ìwọ sínú igi òróró rere lòdì sí ti ẹ̀dá; mélòó mélòó ni a ó lọ́ àwọn wọ̀nyí, tí í ṣe ẹ̀ka-ìyẹ́ka sára igi òróró wọn?
Gbogbo Israẹli tòótọ́ ni yóò ní ìgbàlà
25 (N)Ará, èmi kò ṣá fẹ́ kí ẹ̀yin kí ó wà ní òpè ní ti ohun ìjìnlẹ̀ yìí, kí ẹ̀yin má ba á ṣe ọlọ́gbọ́n ní ojú ara yín, pé ìfọ́jú bá Israẹli ní apá kan, títí kíkún àwọn Kèfèrí yóò fi dé. 26 (O)Bẹ́ẹ̀ ni a ó sì gba gbogbo Israẹli là, gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé:
“Ní Sioni ni Olùgbàlà yóò ti jáde wá,
yóò sì yìí àìwà-bí-Ọlọ́run kúrò lọ́dọ̀ Jakọbu.
27 (P)Èyí sì ni májẹ̀mú mi pẹ̀lú wọn.
Nígbà tí èmi yóò mú ẹ̀ṣẹ̀ wọn kúrò.”
28 Nípa ti ìhìnrere, ọ̀tá ni wọ́n nítorí yín; bí ó sì ṣe ti ìyànfẹ́ ni, olùfẹ́ ni wọ́n nítorí ti àwọn baba. 29 Nítorí àìlábámọ̀ ni ẹ̀bùn àti ìpè Ọlọ́run. 30 Nítorí gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin kò ti gba Ọlọ́run gbọ́ rí, ṣùgbọ́n nísinsin yìí tí ẹ̀yin rí àánú gbà nípa àìgbàgbọ́ wọn. 31 Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni àwọn wọ̀nyí tí ó ṣe àìgbọ́ràn nísinsin yìí, kí àwọn pẹ̀lú bá le rí àánú gbà nípa àánú tí a fihàn yín. 32 (Q)Nítorí Ọlọ́run sé gbogbo wọn mọ́ pọ̀ sínú àìgbàgbọ́, kí ó le ṣàánú fún gbogbo wọn.
Ìyìn fún Ọlọ́run
33 (R)A! Ìjìnlẹ̀ ọ̀rọ̀ àti ọgbọ́n àti ìmọ̀ Ọlọ́run!
Àwámárídìí ìdájọ́ rẹ̀ ti rí,
ọ̀nà rẹ̀ sì jù àwárí lọ!
34 (S)“Nítorí ta ni ó mọ ọkàn Olúwa?
Tàbí ta ni í ṣe ìgbìmọ̀ rẹ̀?”
35 (T)“Tàbí ta ni ó kọ́ fi fún un,
tí a kò sì san padà fún un?”
36 (U)Nítorí láti ọ̀dọ̀ rẹ̀, àti nípa rẹ̀, àti fún un ni ohun gbogbo;
ẹni tí ògo wà fún láéláé! Àmín.
Àsọtẹ́lẹ̀ ní ti Babeli
50 (A)Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Ọlọ́run fi sẹ́nu wòlíì Jeremiah láti sọ fún ará ilẹ̀ Babeli:
2 “Ẹ sọ ọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ẹ sì kéde,
kí ẹ sì gbé àsíá sókè, ẹ kéde rẹ̀
ẹ má sì ṣe bò ó, wí pé,
‘a kó Babeli,
ojú tí Beli,
a fọ́ Merodaki túútúú,
ojú ti àwọn ère rẹ̀,
a fọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀ túútúú.’
3 Àwọn ìlú ní apá àríwá yóò
sì máa gbóguntì wọ́n.
Gbogbo àwọn ènìyàn àti ẹranko ni yóò
sá kúrò ní ìlú yìí.
4 “Ní ọjọ́ wọ̀nyí àti ní àkókò náà,”
ni Olúwa wí,
“Àwọn ọmọ Israẹli yóò jùmọ̀ wá,
àwọn, àti àwọn ọmọ Juda,
wọn yóò lọ pẹ̀lú ẹkún láti ṣàfẹ́rí
Olúwa Ọlọ́run wọn
5 Wọn ó máa béèrè ọ̀nà Sioni, ojú wọn
yóò sì yí síhà ibẹ̀, wí pé ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a
darapọ̀ mọ́ Olúwa ní májẹ̀mú ayérayé,
tí a kì yóò gbàgbé.
6 “Àwọn ènìyàn mi ti jẹ́ àgùntàn tí ó sọnù,
àwọn olùṣọ́-àgùntàn wọn ti jẹ́ kí wọn ṣìnà,
wọ́n ti jẹ́ kí wọn rìn lórí òkè
wọ́n ti lọ láti orí òkè ńlá dé òkè kékeré,
wọn ti gbàgbé ibùsùn wọn.
7 Gbogbo àwọn tí ó rí wọn, ti pa wọ́n jẹ
àwọn ọ̀tá wọ́n sì wí pé, ‘Àwa kò jẹ̀bi
nítorí pé wọ́n ti ṣẹ̀ sí Olúwa ibùgbé
òdodo àti ìrètí àwọn baba wọn.’
8 “Jáde kúrò ní Babeli,
ẹ fi ilẹ̀ àwọn ará Kaldea sílẹ̀,
kí ẹ sì jẹ́ bí òbúkọ níwájú agbo ẹran.
9 Nítorí pé èmi yóò ru,
bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò gbé sókè sí Babeli àwọn orílẹ̀-èdè
ńlá láti ilẹ̀ àríwá. Wọn yóò gba àyà wọn lẹ́gbẹ́ rẹ̀;
Láti àríwá wá, à ó sì mú ọ. Ọfà wọn yóò
dàbí ọfà àwọn akọni akíkanjú tí wọn kì í wà lọ́wọ́ òfo
10 A ó dààmú Babeli, gbogbo
àwọn tó dààmú rẹ yóò sì mú
ìfẹ́ wọn ṣẹ,”
ni Olúwa wí.
11 “Nítorí pé inú yín dùn nítorí pé ẹ̀yìn yọ̀,
ẹ̀yìn olè tí ó jí ìní mi, nítorí tí ẹ̀yìn
fi ayọ̀ fò bí ẹgbọrọ abo màlúù sí koríko tútù,
ẹ sì ń yan bí akọ ẹṣin.
12 Ojú yóò ti ìyá rẹ, ẹni tí ó bí ọ
yóò sì gba ìtìjú.
Òun ni yóò jẹ́ kékeré jù nínú àwọn orílẹ̀-èdè,
ilẹ̀ aṣálẹ̀ àti aginjù tí kò lọ́ràá.
13 Nítorí ìbínú Olúwa, kì yóò ní olùgbé;
ẹnikẹ́ni kò sì ní gbé inú rẹ̀.
Gbogbo àwọn tí ó bá kọjá ni Babeli yóò
fi ṣe yẹ̀yẹ́ nítorí ọgbẹ́ rẹ̀.
14 “Dúró sí ààyè rẹ ìwọ Babeli
àti gbogbo ẹ̀yin tí ẹ n ta ọfà náà.
Ẹ ta ọfà náà sí i, nítorí ó ti ṣẹ̀ sí Olúwa.
15 Kígbe mọ-ọn ní gbogbo ọ̀nà!
Ó tẹríba, òpó rẹ̀ sì yẹ̀,
níwọ̀n ìgbà tí ó ti jẹ́ wí pé èyí ni ìgbẹ̀san Olúwa,
gbẹ̀san lára rẹ̀.
Ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí àwọn ẹlòmíràn.
16 Ké afúnrúgbìn kúrò ní Babeli,
àti ẹni tí ń di dòjé mú ní igà ìkórè!
Nítorí idà àwọn aninilára
jẹ́ kí oníkálùkù padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀,
kí oníkálùkù sì sá padà sí ilẹ̀ rẹ̀.
17 “Israẹli jẹ́ àgùntàn tí ó ṣìnà kiri,
kìnnìún sì ti lé e lọ.
Níṣàájú ọba Asiria pa á jẹ,
àti níkẹyìn yìí Nebukadnessari ọba Babeli
fa egungun rẹ̀ ya.”
18 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli wí;
“Ǹ ó fi ìyà jẹ ọba Babeli àti ilẹ̀ rẹ̀
gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe fìyà jẹ ọba, Asiria.
19 Ṣùgbọ́n, èmi yóò mú Israẹli
padà wá pápá oko tútù rẹ̀
òun yóò sì máa bọ́ ara rẹ̀ lórí Karmeli àti Baṣani,
a ó sì tẹ́ ọkàn rẹ̀ lọ́rùn ní òkè
Efraimu àti ní Gileadi
20 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,”
ni Olúwa wí,
“À ó wá àìṣedéédéé ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli,
ṣùgbọ́n a ki yóò rí ohun;
àti ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a ki yóò sì rí mọ kankan
nítorí èmi yóò dáríjì àwọn tí ó ṣẹ́kù tí mo dá sí.
21 “Kọlu ilẹ̀ Merataimu àti àwọn
tí ó ń gbé ní Pekodi.
Lépa rẹ pa, kí o sì parun pátápátá,”
ni Olúwa wí
“Ṣe gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.
22 Ariwo ogun wà ní ilẹ̀ náà
ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ìparun ńlá.
23 Báwo ni ó ṣe fọ́, tí ó sì pín yẹ́lẹyẹ̀lẹ tó,
lọ́wọ́ òòlù gbogbo ayé!
Báwo ní Babeli ti di ahoro
ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
24 Mo dẹ pàkúté sílẹ̀
fún ọ ìwọ Babeli,
kí o sì tó mọ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀,
o ti kó sínú rẹ̀. A mú ọ nítorí pé o tako Olúwa.
25 Olúwa ti kó àwọn ohun èlò ìjà rẹ̀ jáde,
nítorí pé Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun
ti ṣiṣẹ́ ní ilẹ̀ Babeli.
26 Ẹ wá sórí rẹ̀ láti òpin gbogbo,
sí ilé ìṣúra rẹ̀ sílẹ̀,
ẹ kó o jọ bí òkìtì ọkà,
Kí ẹ sì yà á sọ́tọ̀ fún ìparun,
ẹ má ṣe fí yòókù sílẹ̀ fún un.
27 Pa gbogbo àwọn akọ màlúù rẹ,
jẹ́ kí a kó wọn lọ ibi tí a ó ti pa wọ́n!
Ègbé ní fún wọn! Nítorí ọjọ́ wọn dé,
àkókò ìbẹ̀wò wọn.
28 Gbọ́ ohùn àwọn tí ó sálọ, tí ó sì sálà láti Babeli wá,
sì sọ ní Sioni,
bí Olúwa Ọlọ́run wa ti gbẹ̀san,
ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.
29 “Pe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, àní gbogbo tafàtafà, sórí Babeli,
ẹ dó tí ì yíkákiri, ma jẹ́ ki ẹnikẹ́ni sálà.
Sán fún un gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀
gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí ó ti ṣe,
ẹ ṣe bẹ́ẹ̀ sí i, nítorí tí ó ti gbéraga
sí Olúwa, sí Ẹni Mímọ́ Israẹli.
30 Nítorí náà, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀
yóò ṣubú ní ìgboro, a ó sì pa àwọn
ológun lẹ́nu mọ́,”
ní Olúwa wí.
31 “Wò ó, èmi yóò dojú kọ ọ́ ìwọ agbéraga,”
ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí,
“nítorí ọjọ́ rẹ ti dé,
àkókò tí èmi ó bẹ̀ ọ wò.
32 Onígbèéraga yóò kọsẹ̀, yóò
sì ṣubú, kì yóò sì ṣí ẹni tí yóò gbé dìde.
Èmi yóò tan iná ní ìlú náà,
èyí tí yóò sì jo run.”
33 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ:
“A pọ́n àwọn ènìyàn Israẹli
lójú àti àwọn ènìyàn Juda pẹ̀lú.
Gbogbo àwọn tí ó kó wọn
nígbèkùn dì wọn mú ṣinṣin
wọn kò sì jẹ́ kí ó sá àsálà.
34 Síbẹ̀, Olùràpadà wọn, Alágbára,
Olúwa Ọlọ́run Alágbára ni orúkọ rẹ̀.
Yóò sì gbe ìjà wọn jà,
kí ó ba à lè mú wọn wá sinmi ní ilẹ̀ náà;
ṣùgbọ́n kò sí ìsinmi fún àwọn tí ó ń gbé Babeli.
35 “Idà lórí àwọn Babeli!”
ni Olúwa wí,
“lòdì sí àwọn tó ń gbé ní Babeli,
àwọn aláṣẹ àti àwọn amòye ọkùnrin.
36 Idà lórí àwọn wòlíì èké
wọn yóò di òmùgọ̀! Idà lórí àwọn jagunjagun,
wọn yóò sì kún fún ẹ̀rù.
37 Idà lórí àwọn kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀
àti àwọn àjèjì nínú ẹgbẹ́ rẹ̀.
Wọn yóò di obìnrin.
Idà lórí àwọn ohun ìṣúra rẹ̀!
38 Ilẹ̀ gbígbẹ lórí omi rẹ̀; yóò sì gbẹ.
Nítorí pé ó jẹ́ ilẹ̀ àwọn ère,
àwọn ère tí yóò ya òmùgọ̀ pẹ̀lú ẹ̀rù.
39 “Nítorí náà àwọn ẹranko ijù
pẹ̀lú ọ̀wàwà ni yóò máa gbé ibẹ̀,
abo ògòǹgò yóò sì máa gbé inú rẹ̀,
a kì yóò sì gbé inú rẹ̀ mọ́, láéláé,
bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò ṣàtìpó nínú rẹ̀ láti ìrandíran.
40 Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti gba ìjọba
Sodomu àti Gomorra
pẹ̀lú àwọn ìlú agbègbè wọn,”
ni Olúwa wí,
“kì yóò sí ẹni tí yóò gbé ibẹ̀.
41 “Wò ó! Ọ̀wọ́ ọmọ-ogun láti ìhà àríwá;
orílẹ̀-èdè ńlá àti àwọn ọba púpọ̀ ni à ń
gbé dìde láti òpin ilẹ̀ ayé.
42 Wọ́n sì di ìhámọ́ra ọ̀kọ̀ àti ọrun,
wọ́n burú wọn kò sì ní àánú.
Wọ́n n ké bí i rírú omi bí wọ́n ti ṣe ń gun ẹṣin wọn lọ.
Wọ́n wá bí àkójọpọ̀ ogun láti kọlù ọ́, ìwọ ọmọbìnrin Babeli.
43 Ọba Babeli ti gbọ́ ìròyìn nípa wọn,
ọwọ́ wọn sì rọ,
ìrora mú wọn bí obìnrin tí ó ń rọbí.
44 Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani
sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá,
Èmi ó lé Babeli kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá.
Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀?
Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí?
Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”
45 Nítorí náà, gbọ́ ohun tí
Olúwa sọ nípa Babeli
ẹni tí ó gbìmọ̀ lòdì
sí Babeli; n ó sì pa
agbo ẹran wọn run.
46 Ní ohùn igbe ńlá pé;
a kò Babeli, ilẹ̀ ayé yóò mì tìtì,
a sì gbọ́ igbe náà
láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
Ti Dafidi.
28 Ìwọ Olúwa,
mo ké pe àpáta mi;
Má ṣe kọ etí dídi sí mi.
Tí ìwọ bá dákẹ́ sí mi,
èmí yóò dàbí àwọn tí ó lọ sí ọ̀gbun.
2 Gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi fún àánú,
bí mo ṣe ń ké pè ọ́ fún ìrànlọ́wọ́,
bí mo ṣe gbé àwọn ọwọ́ mi sókè
sí ibi mímọ́ rẹ jùlọ.
3 Má ṣe fà mí lọ pẹ̀lú ènìyàn búburú àti,
pẹ̀lú àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀,
tí ń sọ̀rọ̀ àlàáfíà sí aládùúgbò wọn
ṣùgbọ́n tí ìwà ìkà ń bẹ nínú wọn.
4 San ẹ̀san wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ wọn
àti fún iṣẹ́ ibi wọn;
gba ẹ̀san wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ wọn;
kí o sì san ẹ̀san wọn bí ó ti tọ́.
5 Nítorí pé wọn kò ka iṣẹ́ Olúwa sí,
tàbí àwọn iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀
òun ó rún wọn wọlẹ̀
kì yóò sì gbé wọn ró mọ́.
6 Alábùkún fún ni Olúwa!
Nítorí pé ó ti gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.
7 Olúwa ni agbára mi àti asà mi;
nínú rẹ̀ ni mo gbẹ́kẹ̀lé; àní, ó sì ràn mí lọ́wọ́.
Ọkàn mi sì gbé sókè fún ayọ̀
àní pẹ̀lú orin mi mo fi ọpẹ́ fún un.
8 Olúwa ni agbára àwọn ènìyàn rẹ̀
òun ni odi ìgbàlà àwọn ẹni ààmì òróró rẹ̀.
9 Ìwọ gba àwọn ènìyàn rẹ là, kí o sì bùkún àwọn ajogún rẹ;
di olùṣọ́-àgùntàn wọn, kí o sì gbé wọn lékè títí ayérayé.
Saamu ti Dafidi.
29 Ẹ fi fún Olúwa, ẹ̀yin ẹ̀dá ọ̀run,
Ẹ fi fún Olúwa, ògo àti alágbára.
2 Fi fún Olúwa, àní ògo orúkọ rẹ̀;
sin Olúwa nínú ẹwà ìwà mímọ́.
3 Ohùn Olúwa n ré àwọn omi kọjá;
Ọlọ́run ògo sán àrá,
Olúwa san ara.
4 Ohùn Olúwa ní agbára;
ohùn Olúwa kún fún ọláńlá.
5 Ohùn Olúwa fa igi kedari;
Olúwa náà ló fọ́ igi kedari Lebanoni ya.
6 Ó mú Lebanoni fo bí i ọmọ màlúù,
àti Sirioni bí ọmọ àgbáǹréré.
7 Ohùn Olúwa ń ya
bí ọwọ́ iná mọ̀nà
8 Ohùn Olúwa ń mi aginjù.
Olúwa mi aginjù Kadeṣi.
9 Ohùn Olúwa ní ó lọ igi óákù, ó n mú abo àgbọ̀nrín bí,
ó sì bọ́ igi igbó sí ìhòhò.
Àti nínú tẹmpili rẹ̀ gbogbo ohùn wí pé “Ògo!”
10 Olúwa jókòó, Ó sì jẹ ọba lórí ìṣàn omi;
Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ gẹ́gẹ́ bí Ọba títí láéláé.
11 Kí Olúwa fi agbára fún àwọn ènìyàn rẹ̀;
bùkún àwọn ènìyàn rẹ̀ pẹ̀lú àlàáfíà.
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.