M’Cheyne Bible Reading Plan
Saulu gba ìlú Jabesi sílẹ̀
11 Nahaṣi ará Ammoni gòkè lọ, ó sì dó ti Jabesi Gileadi, gbogbo ọkùnrin Jabesi sì wí fún Nahaṣi pé, “Bá wa dá májẹ̀mú, àwa yóò sì máa sìn ọ́.”
2 Ṣùgbọ́n Nahaṣi ará Ammoni sì wí fún un pé, “Nípa èyí ni èmi yóò fi bá a yín ṣe ìpinnu, nípa yíyọ gbogbo ojú ọ̀tún yín kúrò, èmi yóò ṣì fi yín ṣe ẹlẹ́yà lójú gbogbo Israẹli.”
3 Àwọn àgbàgbà Jabesi sì wí fún un pé, “Fún wa ní ọjọ́ méje kí àwa lè rán oníṣẹ́ sí gbogbo Israẹli; àti agbègbè bí ẹni kankan kò bá sì jáde láti gbà wá, àwa yóò fi ara wa fún ọ.”
4 Nígbà tí àwọn ìránṣẹ́ náà sì wá sí Gibeah tí ó jẹ́ ìlú Saulu, wọ́n sọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún àwọn ènìyàn, gbogbo wọn gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún. 5 Nígbà náà gan an ni Saulu padà wá láti pápá, pẹ̀lú màlúù rẹ̀, ó sì béèrè pé, “kín ni ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí àwọn ènìyàn? Èéṣe tí wọ́n fi ń sọkún?” Nígbà náà ni wọ́n tún sọ fún wọn ọ̀rọ̀ àwọn ọkùnrin Jabesi.
6 Nígbà tí Saulu sì gbọ́ ọ̀rọ̀ wọn, ẹ̀mí Ọlọ́run sì bà lé e pẹ̀lú agbára, inú rẹ̀ sì ru sókè. 7 Ó sì mú màlúù méjì, ó gé wọn sí wẹ́wẹ́, ó sì rán ẹyẹẹyọ sí gbogbo Israẹli nípa ọwọ́ àwọn ìránṣẹ́ náà, ó ní i ẹ kéde pé, “Èyí ni a ó ṣe sí màlúù ẹnikẹ́ni tí kò bá tọ Saulu àti Samuẹli lẹ́yìn.” Nígbà náà ni ìbẹ̀rù Olúwa sì mú àwọn ènìyàn, wọ́n sì jáde bí ènìyàn kan ṣoṣo. 8 Nígbà tí Saulu sì kó wọn jọ ní Beseki, àwọn ọkùnrin Israẹli tí a kà jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún. (300,000) àwọn ọkùnrin Juda sì jẹ́ ẹgbàá-mẹ́ẹ̀ẹ́dógún (30,000).
9 Wọ́n sì sọ fún àwọn ìránṣẹ́ tí ó wá pé, “Sọ fún àwọn ọkùnrin Jabesi Gileadi pé, ní àkókò tí oòrùn bá mú lọ́la, àwa yóò gbà yín sílẹ̀.” Nígbà tí àwọn ìránṣẹ́ náà lọ tí wọ́n sì sọ èyí fún àwọn ọkùnrin Jabesi, inú wọn sì dùn. 10 Wọ́n sọ fún àwọn ará Jabesi pé, “Àwa yóò fi ara wa fún un yín ní ọ̀la, kí ẹ̀yin kí ó ṣe gbogbo èyí tí ó tọ́ lójú yín sí wa.”
11 Ní ọjọ́ kejì Saulu pín àwọn ọkùnrin rẹ̀ sí ipa mẹ́ta, wọ́n sì ya wọ àgọ́ àwọn ará Ammoni ní ìṣọ́ òwúrọ̀, wọ́n sì pa wọ́n títí di ìmóoru ọjọ́. Àwọn tókù wọ́n sì fọ́nká, tó bẹ́ẹ̀ tí méjì wọn kò kù sí ibìkan.
Wọ́n fi ẹsẹ̀ Saulu múlẹ̀ bí ọba
12 Àwọn ènìyàn sọ fún Samuẹli pé, “Ta ni ó béèrè wí pé, Saulu yóò ha jẹ ọba lórí wa? Mú àwọn ọkùnrin náà wá, a ó sì pa wọ́n.”
13 Ṣùgbọ́n Saulu wí pé, “A kì yóò pa ẹnikẹ́ni lónìí, nítorí lónìí yìí ni Olúwa ṣiṣẹ́ ìgbàlà ní Israẹli.”
14 Nígbà náà ni Samuẹli wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a lọ sí Gilgali, kí a lè fi ẹsẹ̀ Saulu múlẹ̀ bí ọba.” 15 Nítorí náà gbogbo ènìyàn lọ sí Gilgali, wọn sí fi Saulu jẹ ọba ní iwájú Olúwa. Níbẹ̀, ni wọn ti rú ẹbọ ìrẹ́pọ̀ ní iwájú Olúwa, Saulu àti gbogbo Israẹli ṣe àjọyọ̀ ńlá.
Ọlọ́run yan Israẹli
9 Òtítọ́ ni èmi ń sọ nínú Kristi, èmi kò ṣèké, ọkàn mi sì ń jẹ́ mi ní ẹ̀rí nínú Ẹ̀mí Mímọ́. 2 Pé mo ní ìbìnújẹ́ púpọ̀, àti ìkáàánú ìgbà gbogbo ni ọkàn mi. 3 (A)Nítorí mo fẹ́rẹ lè gbàdúrà pé kí èmi tìkára mi kúrò lọ́dọ̀ Kristi nítorí àwọn ará mi, àwọn ìbátan mi nípa ti ara. 4 (B)Àwọn ẹni tí i ṣe Israẹli; tí àwọn ẹni tí ìsọdọmọ í ṣe, àti ògo, àti májẹ̀mú, àti ìfúnilófin, àti ìsìn Ọlọ́run, àti àwọn ìlérí. 5 Tí ẹni tí àwọn Baba í ṣe, àti láti ọ̀dọ̀ àwọn ẹni tí Kristi ti wá nípa ti ara, ẹni tí ó borí ohun gbogbo, Ọlọ́run olùbùkún láéláé. Àmín.
6 (C)Ṣùgbọ́n kì í ṣe pé nítorí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run di asán. Kì í sá í ṣe gbogbo àwọn tí ó ti inú Israẹli wá, àwọn ni Israẹli: 7 (D)Bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe pé, nítorí wọ́n jẹ́ irú-ọmọ Abrahamu, gbogbo wọn ni ọmọ: Ní ọ̀nà mìíràn, “Nínú Isaaki ni a ó ti pe irú-ọmọ rẹ̀.” 8 (E)Èyí nì ni pé, kì í ṣe àwọn ọmọ nípa ti ara, ni ọmọ Ọlọ́run: ṣùgbọ́n àwọn ọmọ ìlérí ni a kà ní irú-ọmọ. 9 (F)Nítorí ọ̀rọ̀ ìlérí ni èyí: “Ní ìwòyí àmọ́dún ni èmi yóò wá, Sara yóò sì ní ọmọ ọkùnrin.”
10 (G)Kì í sì í ṣe kìkì èyí; Ṣùgbọ́n nígbà tí Rebeka pẹ̀lú lóyún fún ẹnìkan, fún Isaaki baba wa. 11 Nítorí nígbà tí kò tí ì bí àwọn ọmọ náà, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò tí ì ṣe rere tàbí búburú—kí ìpinnu Ọlọ́run nípa ti ìyànfẹ́ kí ó lè dúró, 12 (H)kì í ṣe nípa ti iṣẹ́, bí kò ṣe ti ẹni tí ń peni—a ti sọ fún un pé, “Ẹ̀gbọ́n ni yóò máa sin àbúrò.” 13 (I)Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé: “Jakọbu ni mo fẹ́ràn, ṣùgbọ́n Esau ni mo kórìíra.”
14 (J)Ǹjẹ́ àwa yóò ha ti wí? Àìṣòdodo ha wà lọ́dọ̀ Ọlọ́run bí? Kí a má ri! 15 (K)Nítorí ó wí fún Mose pé,
“Èmi ó ṣàánú fún ẹni tí èmi yóò ṣàánú fún,
èmi yóò sì ṣe ìyọ́nú fún ẹni tí èmi yóò ṣe ìyọ́nú fún.”
16 Ǹjẹ́ bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe ti ẹni tí ó fẹ́, kì í sì í ṣe ti ẹni tí ń sáré, bí kò ṣe ti Ọlọ́run tí ń ṣàánú. 17 (L)Nítorí ìwé mímọ́ wí fún Farao pé, “Nítorí èyí náà ni mo ṣe gbé ọ dìde, kí èmi kí ó le fi agbára mi hàn lára rẹ, àti kí a bá à le máa ròyìn orúkọ mi ká gbogbo ayé.” 18 (M)Nítorí náà ni ó ṣe ń ṣàánú fún ẹni tí ó wù ú, ẹni tí ó wù ú a sì mú ní ọkàn le.
19 Ìwọ ó sì wí fún mi pé, “Kín ni ó ha tún bá ni wí sí? Nítorí ta ni ó ń de ìfẹ́ rẹ lọ́nà?” 20 (N)Bẹ́ẹ̀ kọ́, ìwọ ènìyàn, tà ni ìwọ tí ń dá Ọlọ́run lóhùn? “Ohun tí a mọ, a ha máa wí fún ẹni tí ó mọ ọ́n pé, ‘Èéṣe tí ìwọ fi mọ mi báyìí?’ ” 21 (O)Amọ̀kòkò kò ha ni agbára lórí amọ̀, nínú ìṣù kan náà láti ṣe apá kan nínú ohun èlò sí ọlá, àti apá kan nínú ohun èlò sí àìlọ́lá?
22 (P)Ǹjẹ́ bí Ọlọ́run bá fẹ́ fi ìbínú rẹ̀ hàn ńkọ́? Tí ó sì fẹ́ sọ agbára rẹ̀ di mí mọ̀, tí ó sì mú sùúrù púpọ̀ fún àwọn ohun èlò ìbínú tí a ṣe fún ìparun; 23 (Q)Àti kí ó lè sọ ọ̀rọ̀ ògo rẹ̀ di mí mọ̀ lára àwọn ohun èlò àánú tí ó ti pèsè ṣáájú fún ògo, 24 (R)Àní àwa, tí ó ti pè, kì í ṣe nínú àwọn Júù nìkan, ṣùgbọ́n nínú àwọn Kèfèrí pẹ̀lú? 25 (S)Bí ó ti wí pẹ̀lú ní Hosea pé,
“Èmi ó pe àwọn tí kì í ṣe ènìyàn mi, ní ènìyàn mi,
àti ẹni tí kí í ṣe àyànfẹ́ ní àyànfẹ́.”
26 (T)Yóò sì ṣe,
“Ní ibi ti a gbé ti sọ fún wọn pé,
‘ẹ̀yin kì í ṣe ènìyàn mi,’
níbẹ̀ ni a ó gbé pè wọ́n ní ‘ọmọ Ọlọ́run alààyè.’ ”
27 (U)Isaiah sì kígbe nítorí Israẹli pé:
“Bí iye àwọn ọmọ Israẹli bá rí bí iyanrìn Òkun,
apá kan ni ó gbàlà.
28 Nítorí Olúwa yóò mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ lórí ilẹ̀ ayé,
yóò parí rẹ̀, yóò sì ké e kúrò ní òdodo.”
29 (V)Àti bí Isaiah ti wí tẹ́lẹ̀:
“Bí kò ṣe bí Olúwa àwọn Ọmọ-ogun
ti fi irú-ọmọ sílẹ̀ fún wa,
àwa ìbá ti dàbí Sodomu,
a bá sì ti sọ wá dàbí Gomorra.”
30 (W)Ǹjẹ́ kí ni àwa ó ha wí? Pé àwọn Kèfèrí, tí kò lépa òdodo, ọwọ́ wọn tẹ òdodo, ṣùgbọ́n òdodo tí ó ti inú ìgbàlà wá ni. 31 (X)Ṣùgbọ́n Israẹli ti ń lépa òfin òdodo, ọwọ́ wọn kò tẹ òfin òdodo. 32 (Y)Nítorí kí ni? Nítorí wọn kò wá a nípa ìgbàgbọ́, ṣùgbọ́n bí ẹni pé nípa iṣẹ́ òfin. Nítorí wọn kọsẹ̀ lára òkúta ìkọ̀sẹ̀ ni; 33 (Z)Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé:
“Kíyèsi, mo gbé òkúta ìkọ̀sẹ̀ kalẹ̀ ní Sioni
àti àpáta tí ó mú wọn ṣubú,
ẹnikẹ́ni ti ó bá sì gbà a gbọ́, ojú kì yóò tì í.”
Àṣọtẹ́lẹ̀ ní tí Moabu
48 (A)Ní ti Moabu:
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí:
“Ègbé ni fún Nebo nítorí a ó parun.
A dójútì Kiriataimu, a sì mú un,
ojú yóò ti alágbára, a ó sì fọ́nká.
2 Moabu kò ní ní ìyìn mọ́,
ní Heṣboni ni wọn ó pète ìparun rẹ̀,
‘Wá, kí a pa orílẹ̀-èdè náà run.’
Àti ẹ̀yin òmùgọ̀ ọkùnrin pàápàá ni a ó pa lẹ́nu mọ́,
a ó fi idà lé e yín.
3 Gbọ́ igbe ní Horonaimu,
igbe ìrora àti ìparun ńlá.
4 Moabu yóò di wíwó palẹ̀;
àwọn ọmọdé rẹ̀ yóò kígbe síta.
5 Wọ́n gòkè lọ sí Luhiti,
wọ́n ń sọkún kíkorò bí wọ́n ti ń lọ;
ní ojú ọ̀nà sí Horonaimu
igbe ìrora ìparun ni à ń gbọ́ lọ.
6 Sá! Àsálà fún ẹ̀mí yín;
kí ẹ sì dàbí aláìní ní aginjù.
7 Níwọ́n ìgbà tí o gbẹ́kẹ̀lé agbára àti ọrọ̀ rẹ,
a ó kó ìwọ náà ní ìgbèkùn,
Kemoṣi náà yóò lọ sí ilẹ̀ ìgbèkùn
pẹ̀lú àlùfáà àti àwọn aláṣẹ rẹ̀.
8 Gbogbo ìlú rẹ ni apanirun yóò dojúkọ,
ìlú kan kò sì ní le là.
Àfonífojì yóò di ahoro
àti ilẹ̀ títẹ́ ni a ó run,
nítorí tí Olúwa ti sọ̀rọ̀.
9 Fi iyọ̀ sí Moabu,
nítorí yóò ṣègbé,
àwọn ìlú rẹ yóò sì di ahoro
láìsí ẹni tí yóò gbé inú rẹ̀.
10 “Ìfibú ni fún ẹni tí ó fi ìmẹ́lẹ́ ṣe iṣẹ́ Olúwa,
ìfibú ni fún ẹni tí ó pa idà mọ́ fún ìtàjẹ̀ sílẹ̀.
11 “Moabu ti wà ní ìsinmi láti ìgbà èwe rẹ̀ wá
bí i ọtí wáìnì lórí gẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀ rẹ̀,
tí a kò dà láti ìgò kan sí èkejì
kò tí ì lọ sí ilẹ̀ ìgbèkùn rí.
Ó dùn lẹ́nu bí ó ti yẹ,
òórùn rẹ̀ kò yí padà.
12 Ṣùgbọ́n ọjọ́ ń bọ̀,”
ni Olúwa wí,
“nígbà tí n ó rán àwọn tí ó n da ọtí láti inú àwọn ìgò
tí wọ́n ó sì dà á síta;
Wọn ó sọ àwọn ìgò rẹ̀ di òfo,
wọn ó sì fọ́ àwọn ife rẹ̀.
13 Nígbà náà Moabu yóò sì tú u nítorí Kemoṣi,
bí ojú ti í ti ilé Israẹli
nígbà tí ó gbẹ́kẹ̀lé Beteli.
14 “Báwo ni o ṣe lè sọ pé, ‘ajagun ni wá,
alágbára ní ogun jíjà’?
15 A ó pa Moabu run, a ó sì gba àwọn ìlú rẹ̀;
a ó sì dúńbú àwọn arẹwà ọkùnrin rẹ̀,”
ni ọba wí, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
16 “Ìṣubú Moabu súnmọ́;
ìpọ́njú yóò dé kánkán.
17 Ẹ dárò fún, gbogbo ẹ̀yin tí ó yí i ká
gbogbo ẹ̀yin tí ẹ mọ bí ó ti ní òkìkí tó.
Ẹ sọ pé, ‘Báwo ni ọ̀pá agbára rẹ
títóbi tí ó sì lógo ṣe fọ́!’
18 “Sọ̀kalẹ̀ níbi ògo rẹ,
kí o sì jókòó ní ilẹ̀ gbígbẹ,
ẹ̀yin olùgbé ọmọbìnrin Diboni,
nítorí tí ẹni tí ó pa Moabu run
yóò dojúkọ ọ́
yóò sì pa àwọn ìlú olódi rẹ run.
19 Dúró lẹ́bàá ọ̀nà kí o sì wòran,
ìwọ tí ń gbé ní Aroeri.
Bí ọkùnrin tí ó sálọ àti obìnrin tí ó ń sá àsálà
‘kí ni ohun tí ó ṣẹlẹ̀?’
20 Ojú ti Moabu nítorí tí a wó o lulẹ̀.
Ẹ hu, kí ẹ sì kígbe!
Ẹ kéde rẹ̀ ní Arnoni pé,
a pa Moabu run.
21 Ìdájọ́ ti dé sí àwọn òkè pẹrẹsẹ
sórí Holoni, Jahisa àti Mefaati,
22 sórí Diboni, Nebo àti Beti-Diblataimu
23 sórí Kiriataimu, Beti-Gamu àti Beti-Meoni,
24 sórí Kerioti àti Bosra,
sórí gbogbo ìlú Moabu, nítòsí àti ní ọ̀nà jíjìn.
25 A gé ìwo Moabu kúrò,
apá rẹ̀ dá,”
ni Olúwa wí.
26 “Ẹ jẹ́ kí a mú u mutí
nítorí ó kó ìdọ̀tí bá Olúwa,
jẹ́ kí Moabu lúwẹ̀ẹ́ nínú èébì rẹ̀,
kí ó di ẹni ẹ̀gàn.
27 Ǹjẹ́ Israẹli kò di ẹni ẹ̀gàn rẹ?
Ǹjẹ́ a kó o pẹ̀lú àwọn olè
tó bẹ́ẹ̀ tí o ń gbọn orí rẹ̀ pẹ̀lú yẹ̀yẹ́
nígbàkúgbà bí a bá sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀?
28 Kúrò ní àwọn ìlú rẹ, kí o sì máa gbé láàrín àwọn òkúta,
ẹ̀yin tí ó ti ń gbé inú ìlú Moabu.
Ẹ dàbí i àdàbà tí ó kọ́ ìtẹ́ rẹ̀
sí ẹnu ihò.
29 “A ti gbọ́ nípa ìgbéraga Moabu:
àti ìwà mo gbọ́n tan rẹ̀
àti ìgbéraga ọkàn rẹ̀.
30 Mo mọ àfojúdi rẹ̀, ṣùgbọ́n òfo ni,”
ni Olúwa wí,
“ìfọ́nnu rẹ̀ kò lè ṣe nǹkan kan.
31 Nítorí náà, mo pohùnréré
ẹkún lórí Moabu fún àwọn
ará Moabu ni mo kígbe lóhùn rara
Mo kẹ́dùn fún àwọn ọkùnrin Kiri-Hareseti.
32 Mo sọkún fún ọ bí Jaseri ṣe sọkún
ìwọ àjàrà Sibma.
Ẹ̀ka rẹ tẹ̀ títí dé Òkun,
wọn dé Òkun Jaseri.
Ajẹnirun ti kọlu èso rẹ,
ìkórè èso àjàrà rẹ.
33 Ayọ̀ àti ìdùnnú ti kúrò
nínú ọgbà àjàrà àti oko Moabu.
Mo dá ọwọ́ ṣíṣàn ọtí wáìnì dúró lọ́dọ̀ olùfúntí;
kò sí ẹni tí ó ń tẹ̀ wọ́n pẹ̀lú igbe ayọ̀
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé igbe wà,
wọn kì í ṣe igbe ti ayọ̀.
34 “Ohùn igbe wọn gòkè
láti Heṣboni dé Eleale àti Jahasi,
láti Soari títí dé Horonaimu àti Eglati-Ṣeliṣi,
nítorí àwọn omi Nimrimu pẹ̀lú yóò gbẹ
35 Ní ti Moabu ni èmi yóò ti fi òpin sí
ẹni tí ó rú ẹbọ ní ibí gíga
àti ẹni tí ń sun tùràrí fún òrìṣà rẹ̀,”
ni Olúwa wí.
36 “Nítorí náà ọkàn mi ró fún Moabu bí fèrè,
ọkàn mi ró bí fèrè fún àwọn ọkùnrin Kiri-Hareseti.
Nítorí ìṣúra tí ó kójọ ṣègbé.
37 Gbogbo orí ni yóò pá,
gbogbo irùngbọ̀n ni a ó gé kúrò,
gbogbo ọwọ́ ni a sá lọ́gbẹ́,
àti aṣọ ọ̀fọ̀ ní gbogbo ẹ̀gbẹ́.
38 Ẹkún ńlá ní yóò wà lórí gbogbo òrùlé Moabu,
àti ní ìta rẹ̀,
nítorí èmi ti fọ́ Moabu
bí a ti ń fọ́ ohun èlò tí kò wu ni,”
ni Olúwa wí.
39 “Èéṣe tí ẹ fi fọ́ túútúú,
tí ẹ sì fi ń pohùnréré ẹkún!
Báwo ni Moabu ṣe yí
ẹ̀yìn padà ní ìtìjú!
Moabu ti di ẹni ìtìjú àti ẹ̀gàn àti
ìdààmú sí gbogbo àwọn tí ó yìí ká.”
40 Báyìí ni Olúwa wí:
“Wò ó ẹyẹ idì náà ń fò bọ̀ nílẹ̀
ó sì na ìyẹ́ rẹ̀ lórí Moabu.
41 Kerioti ni a ó kó lẹ́rú àti ilé agbára ni ó gbà
Ní ọjọ́ náà ọkàn àwọn akọni Moabu
yóò dàbí ọkàn obìnrin tí ó ń rọbí.
42 A ó pa Moabu run gẹ́gẹ́ bí
orílẹ̀-èdè nítorí pé ó gbéraga sí Olúwa.
43 Ẹ̀rù àti ọ̀fìn àti okùn dídè
ń dúró dè yín, ẹ̀yin ènìyàn Moabu,”
ní Olúwa wí.
44 “Ẹnikẹ́ni tí ó bá sá fún
ẹ̀rù yóò ṣubú sínú ọ̀fìn
ẹnikẹ́ni tí o bá jáde síta
nínú ọ̀fìn ní à ó mú
nínú okùn dídè nítorí tí
èmi yóò mú wá sórí
Moabu àní ọdún ìjìyà rẹ,”
ní Olúwa wí.
45 “Ní abẹ́ òjìji Heṣboni
àwọn tí ó sá dúró láìní agbára,
nítorí iná ti jáde wá láti Heṣboni,
àti ọwọ́ iná láti àárín Sihoni,
yóò sì jó iwájú orí Moabu run,
àti agbárí àwọn ọmọ aláriwo.
46 Ègbé ní fún ọ Moabu!
Àwọn ènìyàn orílẹ̀-èdè Kemoṣi ṣègbé
a kó àwọn ọmọkùnrin rẹ lọ sí ilẹ̀ àjèjì
àti àwọn ọmọbìnrin rẹ lọ sí ìgbèkùn.
47 “Síbẹ̀, èmi yóò dá ìkólọ
Moabu padà ní ọjọ́ ìkẹyìn,”
ni Olúwa wí.
Eléyìí ní ìdájọ́ ìkẹyìn lórí Moabu.
Ti Dafidi.
25 Olúwa,
ìwọ ni mo gbé ọkàn mi sókè sí.
2 Ọlọ́run, èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ;
Má ṣe jẹ́ kí ojú ó tì mí
Má ṣe jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi ó yọ̀ mí.
3 Ẹni tí ó dúró tì ọ́
ojú kì yóò tì í,
àwọn tí ń ṣẹ̀ láìnídìí
ni kí ojú kí ó tì.
4 Fi ọ̀nà rẹ hàn mí, Olúwa,
kọ mi ní ipa tìrẹ;
5 ṣe amọ̀nà mi nínú òtítọ́ ọ̀ rẹ, kí o sì kọ́ mi,
Nítorí ìwọ ni Ọlọ́run ìgbàlà mi;
ìwọ ni mo dúró tì ní gbogbo ọjọ́.
6 Rántí, Olúwa àánú àti ìfẹ́ ẹ̀ rẹ̀ ńlá,
torí pé wọ́n ti wà ní ìgbà àtijọ́
7 Má ṣe rántí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ ìgbà èwe mi
tàbí ìrékọjá mi;
gẹ́gẹ́ bí i ìfẹ́ ẹ rẹ̀ rántí mi
nítorí tí ìwọ dára, Ìwọ! Olúwa.
8 Rere àti ẹni ìdúró ṣinṣin ní Olúwa:
nítorí náà, ó kọ́ àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni ọ̀nà náà.
9 Ó ṣe amọ̀nà àwọn onírẹ̀lẹ̀ ni ohun tí ó dára,
ó sì kọ́ àwọn onírẹ̀lẹ̀ ní ọ̀nà rẹ̀.
10 Gbogbo ipa ọ̀nà Olúwa ni ìfẹ́ àti òdodo tí ó dúró ṣinṣin,
fún àwọn tí ó pa májẹ̀mú àti ẹ̀rí rẹ̀ mọ́.
11 Nítorí orúkọ rẹ, Olúwa,
dárí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ mi jì mí, nítorí tí ó tóbi.
12 Àwọn wo ni ó bẹ̀rù Olúwa?
Yóò kọ́ wọn ní ọ̀nà èyí tí wọn yóò yàn.
13 Wọn yóò lo ọjọ́ wọn nínú àlàáfíà,
àwọn ọmọ wọn yóò sì gba ilẹ̀ náà.
14 Olúwa fi ọkàn tán, àwọn tí o bẹ̀rù u rẹ̀;
ó sọ májẹ̀mú rẹ̀ di mí mọ̀ fún wọn.
15 Ojú mi gbé sókè sọ́dọ̀ Olúwa,
nítorí pé yóò yọ ẹsẹ̀ mi kúrò nínú àwọ̀n náà.
16 Yípadà sí mi, kí o sì ṣe oore fún mi;
nítorí pé mo nìkan wà, mo sì di olùpọ́njú.
17 Tì mí lẹ́yìn kúrò nínú ìpọ́njú àyà mi;
kí o sì fà mí yọ kúrò nínú ìpọ́njú mi.
18 Kíyèsi ìjìyà àti wàhálà mi,
kí o sì dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi jì.
19 Kíyèsi ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọ̀tá mi,
tí wọn kórìíra mi pẹ̀lú ìwà ìkà wọn.
20 Pa ọkàn mi mọ́, kí o sì gbà mí sílẹ̀;
Má ṣe jẹ́ kí a fi mí sínú ìtìjú,
nítorí pé ìwọ ni ibi ìsádi mi.
21 Jẹ́ kí òtítọ́ inú àti ìdúró ṣinṣin kí ó pa mí mọ́;
nítorí pé mo dúró tì ọ́.
22 Ra Israẹli padà, Ìwọ Ọlọ́run,
nínú gbogbo ìṣòro rẹ̀!
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.