Print Page Options
Previous Prev Day Next DayNext

Chronological

Read the Bible in the chronological order in which its stories and events occurred.
Duration: 365 days
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Version
Òwe 4-6

Ọgbọ́n ni o ga jùlọ

Tẹ́tí, Ẹ̀yin ọmọ mi, sí ẹ̀kọ́ baba; fetísílẹ̀ kí o sì ní òye sí i
Mo fún ọ ní ẹ̀kọ́ tí ó yè kooro
    Nítorí náà má ṣe kọ ẹ̀kọ́ mi sílẹ̀
Nígbà tí mo jẹ́ ọ̀dọ́mọkùnrin ní ilé baba à mí,
    mo jẹ́ èwe, tí mo sì jẹ́ ọ̀kan ṣoṣo lọ́wọ́ ìyá mi
Ó kọ́ mi ó sì wí pé
    “Jẹ́ kí àyà rẹ kí ó gba ọ̀rọ̀ mi dúró,
pa òfin mi mọ́, kí ìwọ kí ó sì yè.
Gba ọgbọ́n, gba òye,
    Má ṣe gbàgbé ọ̀rọ̀ mi tàbí kí o yẹsẹ̀ kúrò nínú rẹ̀
Má ṣe kọ ọgbọ́n sílẹ̀, yóò sì dáàbò bò ọ́,
    fẹ́ràn rẹ̀, yóò sì bojútó ọ.
Ọgbọ́n ni ó ga jù; nítorí náà gba ọgbọ́n.
    Bí ó tilẹ̀ ná gbogbo ohun tí o ní, gba òye
Gbé e ga, yóò sì gbé ọ ga
    dìrọ̀ mọ́ ọn, yóò sì bu iyì fún ọ.
Yóò fi òdòdó ọ̀ṣọ́ ẹwà sí orí rẹ
    yóò sì fi adé ẹlẹ́wà fún ọ.”

10 Tẹ́tí, ọmọ mi, gba ohun tí mo sọ,
    Ọjọ́ ayé è rẹ yóò sì gùn.
11 Mo tọ́ ọ ṣọ́nà ní ọ̀nà ti ọgbọ́n
    mo sì mú ọ lọ ní ọ̀nà ti tààrà.
12 Nígbà tí o rìn, ìgbésẹ̀ rẹ kò ní ní ìdíwọ́
    nígbà tí o bá sáré, ìwọ kì yóò kọsẹ̀.
13 Di ẹ̀kọ́ mú, má ṣe jẹ́ kí ó lọ;
    tọ́jú u rẹ̀ dáradára nítorí òun ni ìyè rẹ.
14 Má ṣe gbé ẹsẹ̀ rẹ sí ojú ọnà àwọn ènìyàn búburú
    tàbí kí o rìn ní ọ̀nà àwọn ẹni ibi.
15 Yẹra fún un, má ṣe rìn níbẹ̀;
    yàgò fún un kí o sì bá ọ̀nà tìrẹ lọ
16 Nítorí wọn kò le sùn àyàfi tí wọ́n bá ṣe ibi,
    wọn kò ní tòògbé àyàfi tí wọ́n bá gbé ẹlòmíràn ṣubú
17 Wọ́n ń jẹ oúnjẹ ìwà búburú
    wọ́n sì ń mu wáìnì ìwà ìkà.

18 Ipa ọ̀nà olódodo dàbí àṣẹ̀ṣẹ̀yọ oòrùn
    tí ń tànmọ́lẹ̀ sí i títí ọjọ́ fi kanrí
19 ṣùgbọ́n ọ̀nà ènìyàn búburú dàbí òkùnkùn biribiri;
    wọn kò mọ ohun tí ó ń mú wọn kọsẹ̀.

20 Ọmọ mi, tẹ́tí sí ohun tí mo sọ;
    fetísílẹ̀ dáradára sí ọ̀rọ̀ mi
21 Má ṣe jẹ́ kí wọ́n rá mọ́ ọ lójú
    pa wọ́n mọ́ sínú ọkàn rẹ;
22 Nítorí ìyè ni wọ́n jẹ́ fún gbogbo ẹni tí ó rí wọn
    àti ìlera fún gbogbo ara ènìyàn
23 Ju gbogbo nǹkan tókù lọ, pa ọkàn rẹ mọ́
    Nítorí òun ni orísun ìyè,
24 Mú àrékérekè kúrò ní ẹnu rẹ;
    sì jẹ́ kí ọ̀rọ̀ ìsọkúsọ jìnnà réré sí ẹnu rẹ.
25 Jẹ́ kí ojú rẹ máa wo iwájú,
    jẹ́ kí ìwo ojú rẹ máa wo ọ̀kánkán iwájú rẹ sá á.
26 (A)Kíyèsi ìrìn ẹsẹ̀ rẹ
    sì rìn ní àwọn ọ̀nà tí ó dára nìkan
27 Má ṣe yà sọ́tùn ún tàbí sósì;
    pa ẹsẹ̀ rẹ mọ́ kúrò nínú ibi.

Ìkìlọ̀ láti yàgò fún àgbèrè

Ọmọ mi, fiyèsí ọgbọ́n mi,
    kí o sì dẹtí rẹ sí òye mi,
Kí ìwọ sì lè ní ìṣọ́ra
    kí ètè rẹ sì le pa ìmọ̀ mọ́.
Nítorí ètè àwọn àjèjì obìnrin a máa sun bi oyin,
    ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì kúnná ju òróró lọ.
Ṣùgbọ́n ní ìgbẹ̀yìn gbẹ́yín, ó korò ju òróǹró lọ,
    ó mú bí idà olójú méjì.
Ẹsẹ̀ rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ lọ sí ọ̀nà ikú
    ìgbésẹ̀ rẹ̀ lọ tààrà sí ibojì òkú.
Kí ìwọ má ba à já ipa ọ̀nà ìyè;
    ọ̀nà rẹ̀ rí pálapàla, ṣùgbọ́n kò tilẹ̀ mọ́.

Nítorí náà, ẹ̀yin ọmọ mi, ẹ dẹtí sí mi,
    kí ẹ̀yin kí ó má ṣe yàgò kúrò nínú ọ̀rọ̀ tí mo sọ.
Rìn ní ọ̀nà tí ó jìnnà sí ti rẹ̀,
    má ṣe súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà ilé rẹ̀
Àìṣe bẹ́ẹ̀ ìwọ yóò gbé gbogbo ọlá rẹ lé ẹlòmíràn lọ́wọ́
    àti ọjọ́ ayé rẹ fún ìkà ènìyàn.
10 Kí a má ba à fi ọrọ̀ rẹ fún àjèjì ènìyàn,
    kí làálàá rẹ sì sọ ilé ẹlòmíràn di ọlọ́rọ̀.
11 Ní ìgbẹ̀yìn ayé rẹ ìwọ yóò kérora,
    nígbà tí agbára rẹ àti ara rẹ bá ti joro tán
12 Ìwọ yóò wí pé, “Mo ti kórìíra ẹ̀kọ́ tó!
    Ọkàn mi ṣe wá kórìíra ìbáwí!
13 N kò gbọ́rọ̀ sí àwọn olùkọ́ mi lẹ́nu,
    tàbí kí n fetí sí àwọn tí ń kọ́ mi lẹ́kọ̀ọ́.
14 Mo ti bẹ̀rẹ̀ ìparun pátápátá
    ní àárín gbogbo àwùjọ ènìyàn.”

15 Mu omi láti inú kànga tìrẹ
    Omi tí ń sàn láti inú kànga rẹ.
16 Ó ha yẹ kí omi ìsun rẹ kún àkúnya sí ojú ọ̀nà
    àti odò tí ń sàn lọ sí àárín ọjà?
17 Jẹ́ kí wọn jẹ́ tìrẹ nìkan,
    má ṣe ṣe àjọpín wọn pẹ̀lú àjèjì láéláé.
18 Jẹ́ kí orísun rẹ kí ó ní ìbùkún;
    kí ìwọ ó sì máa yọ nínú aya ìgbà èwe rẹ.
19 Abo àgbọ̀nrín tó dára, ìgalà tí ó wu ni jọjọ,
    Jẹ́ kí ọmú rẹ̀ kí ó máa fi ayọ̀ fún ọ nígbà gbogbo,
    kí o sì máa yọ̀ nínú ìfẹ́ rẹ̀ nígbàkúgbà.
20 Ọmọ mi, èéṣe tí ìwọ ó fi máa yọ̀ nínú ìfẹ́ obìnrin panṣágà,
    tí ìwọ ó sì fi dì mọ́ ìyàwó ẹlòmíràn?

21 Nítorí ọ̀nà ènìyàn kò fi ara sin rárá fún Olúwa
    Ó sì ń gbé gbogbo ọ̀nà rẹ̀ yẹ̀ wò
22 Ìwà búburú ènìyàn búburú ni yóò mú kó bọ́ sínú okùn;
    okùn ẹ̀ṣẹ̀ ara rẹ̀ yóò sì dìímú.
23 Yóò kú ní àìgba ẹ̀kọ́
    ìwà òmùgọ̀ ara rẹ̀ yóò sì mú kí ó máa ṣìnà kiri.

Ìkìlọ̀ láti ṣọ́ra fún ìwà òmùgọ̀

Ọmọ mi, bí ìwọ bá ṣe onídùúró fún aládùúgbò rẹ,
    bí ìwọ bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún àjèjì ènìyàn,
bí a bá ti fi ọ̀rọ̀ tí ó sọ dẹkùn mú ọ,
    tí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ ti kó ọ sí pàkúté,
Nígbà náà, ṣe èyí, ìwọ ọmọ mi, láti gba ara rẹ
    níwọ̀n bí o ti kó ṣọ́wọ́ aládùúgbò rẹ:
lọ kí o sì rẹ ara rẹ sílẹ̀;
    bẹ aládùúgbò rẹ dáradára
Má ṣe jẹ́ kí oorun kí ó kùn ọ́,
    tàbí kí o tilẹ̀ tòògbé rárá.
Gba ara rẹ sílẹ̀, bí abo èsúró kúrò lọ́wọ́ ọdẹ,
    bí ẹyẹ kúrò nínú okùn àwọn pẹyẹpẹyẹ.

Tọ èèrà lọ, ìwọ ọ̀lẹ
    kíyèsi ìṣe rẹ̀, kí o sì gbọ́n!
Kò ní olùdarí,
    kò sí alábojútó tàbí ọba,
síbẹ̀, a kó ìpèsè rẹ̀ jọ ní àsìkò òjò
    yóò sì kó oúnjẹ rẹ̀ jọ ní àsìkò ìkórè.

Yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò dùbúlẹ̀, ìwọ ọ̀lẹ?
    Nígbà wo ni ìwọ yóò jí kúrò lójú oorun rẹ?
10 Oorun díẹ̀, òògbé díẹ̀,
    ìkáwọ́gbera láti sinmi díẹ̀
11 Òsì yóò sì wá sórí rẹ bí ìgárá ọlọ́ṣà
    àti àìní bí adigunjalè.

12 Ènìyànkénìyàn àti ènìyàn búburú,
    tí ń ru ẹnu àrékérekè káàkiri,
13 tí ó ń ṣẹ́jú pàkòpàkò,
    ó ń fi ẹsẹ̀ rẹ̀ sọ̀rọ̀
    ó sì ń fi ìka ọwọ́ rẹ̀ júwe,
14 tí ó ń pète búburú pẹ̀lú ẹ̀tàn nínú ọkàn rẹ̀
    ìgbà gbogbo ni ó máa ń dá ìjà sílẹ̀.
15 Nítorí náà ìdààmú yóò dé bá a ní ìṣẹ́jú akàn;
    yóò parun lójijì láìsí àtúnṣe.

16 Àwọn ohun mẹ́fà wà tí Olúwa kórìíra,

ohun méje ní ó jẹ́ ìríra sí i:

17 Ojú ìgbéraga,

Ahọ́n tó ń parọ́

ọwọ́ tí ń ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀,

18 ọkàn tí ń pète ohun búburú,

ẹsẹ̀ tí ó yára láti sáré sínú ìwà ìkà,

19 Ajẹ́rìí èké tí ń tú irọ́ jáde lẹ́nu

àti ènìyàn tí ń dá ìjà sílẹ̀ láàrín àwọn ọmọ ìyá kan.

Ìkìlọ̀ nítorí àgbèrè

20 Ọmọ mi, pa àṣẹ baba rẹ mọ́
    má sì ṣe kọ ẹ̀kọ́ ìyá rẹ sílẹ̀.
21 Jẹ́ kí wọn wà nínú ọkàn rẹ láéláé
    so wọ́n mọ́ ọrùn rẹ
22 Nígbà tí ìwọ bá ń rìn, wọn yóò ṣe amọ̀nà rẹ;
    nígbà tí ìwọ bá sùn, wọn yóò máa ṣe olùṣọ́ rẹ;
    nígbà tí o bá jí, wọn yóò bá ọ sọ̀rọ̀.
23 Nítorí àwọn àṣẹ yìí jẹ́ fìtílà,
    ẹ̀kọ́ yìí jẹ́ ìmọ́lẹ̀,
    àti ìtọ́nisọ́nà ti ìbáwí
    ni ọ̀nà sí ìyè.
24 Yóò pa ọ́ mọ́ kúrò lọ́wọ́ obìnrin búburú,
    kúrò lọ́wọ́ ẹnu dídùn obìnrin àjèjì.

25 Má ṣe ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ si nínú ọkàn rẹ nítorí ẹwà rẹ
    tàbí kí o jẹ́ kí ó fi ojú rẹ̀ fà ọ́ mọ́ra.

26 Nítorí pé nípasẹ̀ àgbèrè obìnrin ni ènìyàn fi ń di oníṣù-àkàrà kan,
    ṣùgbọ́n àyà ènìyàn a máa wá ìyè rẹ̀ dáradára.
27 Ǹjẹ́ ọkùnrin ha le è gbé iná lé orí itan
    kí aṣọ rẹ̀ má sì jóná?
28 Ǹjẹ́ ènìyàn le è máa rìn lórí iná?
    Kí ẹsẹ̀ rẹ̀ sì má jóná?
29 Bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ń lọ sùn pẹ̀lú aya aláya;
    kò sí ẹni tí ó fọwọ́ kàn án tí yóò lọ láìjìyà.

30 Àwọn ènìyàn kì í kẹ́gàn olè tí ó bá jalè
    nítorí àti jẹun nígbà tí ebi bá ń pa á.
31 Síbẹ̀ bí ọwọ́ bá tẹ̀ ẹ́, ó gbọdọ̀ san ìlọ́po méje
    bí ó tilẹ̀ kó gbogbo ohun tó ní nílé tà.
32 Ṣùgbọ́n ẹni tí ń ṣe àgbèrè kò nírònú;
    ẹnikẹ́ni tí ó bá ń ṣe bẹ́ẹ̀ ó ń pa ara rẹ̀ run ni
33 Ìfarapa àti ìtìjú ni tirẹ̀,
    ẹ̀gàn rẹ̀ kì yóò sì kúrò láéláé.

34 Nítorí owú yóò ru ìbínú ọkọ sókè,
    kì yóò sì ṣàánú nígbà tí ó bá ń gbẹ̀san.
35 Kò nígbà nǹkan kan bí ohun ìtánràn;
    yóò kọ àbẹ̀tẹ́lẹ̀, bí ó ti wù kí ó pọ̀ tó.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)

Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.