Revised Common Lectionary (Complementary)
Saamu. Orin. Fún ìyàsímímọ́ Tẹmpili. Ti Dafidi.
30 Èmi yóò kókìkí i rẹ, Olúwa,
nítorí ìwọ ni ó gbé mi lékè
tí ìwọ kò sì jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi kí ó yọ̀ mí.
2 Olúwa Ọlọ́run mi, èmi ké pè ọ́, fún ìrànlọ́wọ́
ìwọ sì ti wò mí sàn.
3 Olúwa, ìwọ ti yọ ọkàn mi jáde kúrò nínú isà òkú,
mú mi padà bọ̀ sípò alààyè kí èmi má ba à lọ sínú ihò.
4 Kọ orin ìyìn sí Olúwa, ẹ̀yin olódodo;
kí ẹ sì fi ọpẹ́ fún orúkọ rẹ̀ mímọ́.
5 Nítorí pé ìbínú rẹ̀ wà fún ìgbà díẹ̀,
ojúrere rẹ̀ wà títí ayérayé;
Ẹkún lè pẹ́ títí di alẹ́,
Ṣùgbọ́n ayọ̀ yóò wá ní òwúrọ̀.
6 Ní ìgbà ayé mi, mo wí pé,
“a kì yóò ṣí mi ní ipò padà.”
7 Nípa ojúrere rẹ, Olúwa,
ìwọ ti gbé mi kalẹ̀ bí òkè tí ó ní agbára;
ìwọ pa ojú rẹ mọ́,
àyà sì fò mí.
8 Sí ọ Olúwa, ni mo ké pè é;
àti sí Olúwa ni mo sọkún fún àánú:
9 “Èrè kí ni ó wà nínú ikú ìparun mi,
nínú lílọ sí ihò mi?
Eruku yóò a yìn ọ́ bí?
Ǹjẹ́ yóò sọ nípa òdodo rẹ?
10 Gbọ́, Olúwa, kí o sì ṣàánú fún mi;
ìwọ Olúwa, jẹ́ olùrànlọ́wọ́ mi.”
11 Ìwọ ti yí ìkáàánú mi di ijó fún mi;
ìwọ sì ti bọ́ aṣọ ọ̀fọ̀ mi, o sì fi aṣọ ayọ̀ wọ̀ mí,
12 nítorí ìdí èyí ni kí ọkàn mi máa yìn ọ́, kí o má sì ṣe dákẹ́.
Ìwọ Olúwa Ọlọ́run mi, èmi yóò máa fi ọpẹ́ fún ọ títí láé.
2 Báwo ni Olúwa ṣe bo ọmọbìnrin Sioni
pẹ̀lú àwọsánmọ̀ ìbínú rẹ̀!
Ó sọ ògo Israẹli kalẹ̀
Láti ọ̀run sí ayé;
kò rántí àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀
ní ọjọ́ ìbínú rẹ̀.
2 Láìní àánú ni Olúwa gbé
ibùgbé Jakọbu mì;
nínú ìrunú rẹ̀, ni ó wó
ibi gíga ọmọbìnrin Juda lulẹ̀.
Ó ti mú ìjọba àti àwọn ọmọ-aládé ọkùnrin
lọ sínú ilẹ̀ ní àìlọ́wọ̀.
3 Ní ìbínú gbígbóná rẹ̀ ni ó ké
gbogbo ìwo Israẹli.
Ó ti mú ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ kúrò
nígbà tí àwọn ọ̀tá dé.
Ó run ní Jakọbu bí ọ̀wọ́-iná
ní àgọ́ àwọn ọmọbìnrin Sioni.
4 Ó na ọfà rẹ̀ bí ọ̀tá;
ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ sì múra
Bí ti ọ̀tá tí ó ti parun
ó tú ìbínú rẹ̀ jáde bí iná
sórí àgọ́ ọmọbìnrin Sioni.
5 Olúwa dàbí ọ̀tá;
ó gbé Israẹli mì.
Ó ti gbé gbogbo ààfin rẹ̀ mì
ó pa ibi gíga rẹ̀ run.
Ó sọ ìmí ẹ̀dùn àti ìbànújẹ́ di púpọ̀
fún àwọn ọmọbìnrin Juda.
6 Ó mú ìparun bá ibi mímọ́,
ó pa ibi ìpàdé rẹ̀ run.
Olúwa ti mú Sioni gbàgbé
àjọ̀dún tí a yàn àti ọ̀sẹ̀ tí ó yàn;
nínú ìbínú gbígbóná rẹ̀ ni ó run
ọba àti olórí àlùfáà.
7 Olúwa ti kọ̀ pẹpẹ rẹ̀ sílẹ̀
ó sì ti kọ̀ ibi mímọ́ rẹ̀.
Ó sì fi lé ọ̀tá lọ́wọ́
àwọn odi ààfin rẹ̀;
wọ́n sì kígbe ní ilé Olúwa
gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ àpèjẹ tí a yàn.
8 Olúwa pinnu láti fa
ògiri tí ó yí ọmọbìnrin Sioni ya.
Ó gbé wọn sórí òṣùwọ̀n,
kò sì fa ọwọ́ rẹ̀ padà kúrò nínú ìparun wọn.
Ó mú kí ilé ìṣọ́ àti odi rẹ̀ ṣọ̀fọ̀
wọ́n ṣòfò papọ̀.
9 Ẹnu-ọ̀nà rẹ̀ ti wọ inú ilẹ̀;
òpó rẹ̀ ni ó wó tí ó sì ti bàjẹ́.
Ọba àti ọmọ ọbakùnrin rẹ̀ wà ní ìgbèkùn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,
kò sí òfin mọ́,
àwọn wòlíì rẹ̀ kò rí
ìran láti ọ̀dọ̀ Olúwa mọ́.
10 Àwọn àgbàgbà ọmọbìnrin Sioni
jókòó sílẹ̀ ní ìdákẹ́rọ́rọ́;
wọ́n da eruku sí orí wọn
wọ́n sì wọ aṣọ àkísà.
Àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin Jerusalẹmu
ti tẹrí wọn ba sí ilẹ̀.
11 Ojú mi kọ̀ láti sọkún,
mo ń jẹ ìrora nínú mi,
mo tú ọkàn mi jáde sí ilẹ̀
nítorí a pa àwọn ènìyàn mí run,
nítorí àwọn ọmọdé àti ọmọ ọwọ́ ń kú
ní òpópó ìlú.
12 Wọ́n wí fún àwọn ìyá wọn,
“Níbo ni ọkà àti wáìnì wà?” Wò ó
bí wọ́n ṣe ń kú lọ bí àwọn ọkùnrin tí a ṣe léṣe
ní àwọn òpópónà ìlú,
bí ayé wọn ṣe ń ṣòfò
láti ọwọ́ ìyá wọn.
Ọ̀rọ̀ ìyànjú lórí ìfifúnni
8 Pẹ̀lúpẹ̀lú, ará, àwa ń sọ fún yín ní ti oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run tí a fífún àwọn ìjọ Makedonia; 2 Bí ó ti jẹ́ pé a dán wọn wò nípa ìpọ́njú, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ayọ̀ àti àìlódiwọ̀n àìní wọn ti kún àkúnwọ́sílẹ̀ nínú ọ̀rọ̀ ìlawọ́ wọn. 3 (A)Nítorí mo jẹ́rìí pé gẹ́gẹ́ bí agbára wọn, àní ju agbára wọn, wọ́n ṣe é láti ìfẹ́ inú ara wọn. 4 (B)Wọ́n ń fi ẹ̀bẹ̀ púpọ̀ rọ̀ wá ní ti ẹ̀bùn àtinúwá yìí, láti ba à lè ní ìpín nínú iṣẹ́ ìránṣẹ́ fún àwọn ènìyàn mímọ́. 5 Àti èyí, kì í ṣe bí àwa tí rò rí, ṣùgbọ́n wọ́n tètè kọ́ fi àwọn fúnrawọn fún Olúwa, àti fún wá, nípa ìfẹ́ Ọlọ́run. 6 (C)Tó bẹ́ẹ̀ tí àwa fi gba Titu níyànjú pé, bí ó tí bẹ̀rẹ̀ náà, bẹ́ẹ̀ ni kí ó sì parí ẹ̀bùn ọ̀fẹ́ yìí nínú yín pẹ̀lú. 7 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin ti pọ̀ lóhùn gbogbo, ní ìgbàgbọ́, àti ọ̀rọ̀ àti ìmọ̀, àti nínú iṣẹ́ ìhìnrere gbogbo, àti ní ìfẹ́ yín sí wa, ẹ rí i wí pé ẹ̀yin pọ̀ sí i nínú ẹ̀bùn ọ̀fẹ́ yìí pẹ̀lú.
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.