Revised Common Lectionary (Complementary)
Saamu ti Dafidi.
23 Olúwa ni Olùṣọ́ èmi àgùntàn rẹ̀, èmi kì yóò ṣe aláìní.
2 (A)Ó mú mi dùbúlẹ̀ sí ibi pápá oko tútù
Ó mú mi lọ sí ibi omi dídákẹ́ rọ́rọ́;
3 Ó mú ọkàn mi padà bọ̀ sípò
Ó mú mi lọ sí ọ̀nà òdodo
nítorí orúkọ rẹ̀.
4 Bí mo tilẹ̀ ń rìn
Láàrín àfonífojì òjìji ikú,
èmi kì yóò bẹ̀rù ibi kan;
nítorí ìwọ wà pẹ̀lú mi;
ọ̀gọ rẹ àti ọ̀pá à rẹ
wọ́n ń tù mí nínú.
5 Ìwọ tẹ́ tábìlì oúnjẹ sílẹ̀ níwájú mi
ní ojú àwọn ọ̀tá à mi;
ìwọ ta òróró sí mi ní orí;
ago mí sì kún àkúnwọ́sílẹ̀.
6 Nítòótọ́, ìre àti àánú ni yóò máa tọ̀ mí lẹ́yìn
ní ọjọ́ ayé è mi gbogbo,
èmi yóò sì máa gbé inú ilé Olúwa
títí láéláé.
Àsọtẹ́lẹ̀ kan nípa Jerusalẹmu
22 Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó jẹ mọ́ Àfonífojì ìran:
Kí ni ó ń dààmú yín báyìí,
tí gbogbo yín fi gun orí òrùlé lọ?
2 Ìwọ ìlú tí ó kún fún rúkèrúdò,
ìwọ ìlú àìtòrò òun rògbòdìyàn
a kò fi idà pa àwọn òkú rẹ,
bẹ́ẹ̀ ni wọn kò kú ní ojú ogun.
3 Gbogbo àwọn olórí i yín ti jùmọ̀ sálọ;
a ti kó wọn nígbèkùn láìlo ọfà.
Ẹ̀yin tí a mú ni a ti kó lẹ́rú papọ̀,
lẹ́yìn tí ẹ ti sá nígbà tí ọ̀tá ṣì wà
lọ́nà jíjìn réré.
4 Nítorí náà ni mo wí pé, “Yípadà kúrò lọ́dọ̀ mi:
jẹ́ kí n sọkún kíkorò.
Má ṣe gbìyànjú àti tù mí nínú
nítorí ìparun àwọn ènìyàn mi.”
5 Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ọjọ́ kan
tí rúkèrúdò, rògbòdìyàn àti ẹ̀rùjẹ̀jẹ̀
ní Àfonífojì ìmọ̀,
ọjọ́ tí a ń wó ògiri lulẹ̀
àti sísun ẹkún lọ sí àwọn orí òkè.
6 Elamu mú apó-ọfà lọ́wọ́,
pẹ̀lú àwọn agun-kẹ̀kẹ́-ogun àti àwọn ẹṣin,
Kiri yọ àpáta rẹ̀ síta.
7 Àyànfẹ́ Àfonífojì rẹ kún fún kẹ̀kẹ́ ogun,
àwọn ẹlẹ́ṣin ni a gbá jọ sí ẹnu-bodè ìlú.
8 Gbogbo ààbò Juda ni a ti ká kúrò.
Ìwọ sì gbójú sókè ní ọjọ́ náà
sí àwọn ohun ìjà ní ààfin ti inú aginjù,
Sí àwọn alàgbà àti àwọn ọ̀dọ́kùnrin
5 Àwọn alàgbà tí ń bẹ láàrín yín ni mo gbànímọ̀ràn, èmi ẹni tí ń ṣe alàgbà bí ẹ̀yin, àti ẹlẹ́rìí ìyà Kristi, àti alábápín nínú ògo tí a ó fihàn: 2 Ẹ máa tọ́jú agbo Ọlọ́run tí ń bẹ láàrín yín, ẹ máa bojútó o, kì í ṣe àfipáṣe, bí kò ṣe tìfẹ́tìfẹ́; kó má sì jẹ́ fún èrè ìjẹkújẹ, bí kò ṣe pẹ̀lú ìpinnu tí ó múra tan. 3 Bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe bí ẹni tí ń lo agbára lórí ìjọ, ṣùgbọ́n kí ẹ ṣe ara yín ní àpẹẹrẹ fún agbo. 4 Nígbà tí olórí Olùṣọ́-àgùntàn bá sì fi ara hàn, ẹ̀yin ó gba adé ògo ti kì í sá.
5 (A)Bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú, ẹ̀yin ọ̀dọ́, ẹ tẹríba fún àwọn alàgbà. Àní, gbogbo yín ẹ máa tẹríba fún ara yín kí ẹ fi ìrẹ̀lẹ̀ wọ ara yín ní aṣọ: nítorí,
“Ọlọ́run kọ ojú ìjà sí àwọn agbéraga,
ṣùgbọ́n ó ń fi oore-ọ̀fẹ́ fún àwọn onírẹ̀lẹ̀.”
Àwọn ìkíni ìkẹyìn
12 Nítorí Sila, arákùnrin wa olóòtítọ́ gẹ́gẹ́ bí mo ti kà á sí, ni mo kọ̀wé kúkúrú sí i yín, tí mo ń gbà yín níyànjú, tí mo sì ń jẹ́rìí pé, èyí ni òtítọ́ oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run: ẹ dúró ṣinṣin nínú rẹ̀.
13 Ìjọ tí ń bẹ ní Babeli, tí a yàn, pẹ̀lú kí yín, bẹ́ẹ̀ sì ni Marku ọmọ mi pẹ̀lú.
14 Ẹ fi ìfẹ́nukonu ìfẹ́ kí ara, yín.
Àlàáfíà fún gbogbo yín tí ẹ wà nínú Kristi.
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.