Old/New Testament
Àwọn ará Gibeoni gba ẹ̀san
21 Ìyàn kan sì mú lọ́jọ́ Dafidi ní ọdún mẹ́ta, láti ọdún dé ọdún; Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa, Olúwa sì wí pé, Nítorí ti Saulu ni, àti nítorí ilé rẹ̀ tí ó kún fún ẹ̀jẹ̀, nítorí pé ó pa àwọn ará Gibeoni.
2 Ọba sì pe àwọn ará Gibeoni, ó sì bá wọn sọ̀rọ̀; àwọn ará Gibeoni kì í ṣe ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Israẹli, ṣùgbọ́n wọ́n jẹ́ àwọn tí ó kù nínú àwọn ọmọ Amori; àwọn ọmọ Israẹli sì ti búra fún wọn: Saulu sì ń wá ọ̀nà àti pa wọ́n ní ìtara rẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli àti Juda. 3 Dafidi sì bi àwọn ará Gibeoni léèrè pé, “Kí ni èmi ó ṣe fún un yín? Àti kín ni èmi ó fi ṣe ètùtù, kí ẹ̀yin lè súre fún ilẹ̀ ìní Olúwa?”
4 Àwọn ará Gibeoni sì wí fún un pé, “Kì í ṣe ọ̀rọ̀ fàdákà tàbí wúrà láàrín wa àti Saulu tàbí ìdílé rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni a kò sì fẹ́ kí ẹ pa ẹnìkan ní Israẹli.”
Dafidi sì wí pé, “Èyí tí ẹ̀yin bá wí ni èmi ó ṣe?”
5 Wọ́n sì wí fún ọba pé, “Ọkùnrin tí ó run wá, tí ó sì rò láti pa wá rẹ́ ki a má kù níbikíbi nínú gbogbo agbègbè Israẹli. 6 Mú ọkùnrin méje nínú àwọn ọmọ rẹ̀ fún wá, àwa ó sì so wọ́n rọ̀ fún Olúwa ní Gibeah ti Saulu ẹni tí Olúwa ti yàn.”
Ọba sì wí pé, “Èmi ó fi wọ́n fún yín.”
Síso Àwọn Ènìyàn Saulu Méje Rọ̀
7 Ṣùgbọ́n ọba dá Mefiboṣeti sí, ọmọ Jonatani, ọmọ Saulu, nítorí ìbúra Olúwa tí ó wà láàrín Dafidi àti Jonatani ọmọ Saulu. 8 Ọba sì mú àwọn ọmọkùnrin méjèèjì tí Rispa ọmọbìnrin Aiah bí fún Saulu, àní Ammoni àti Mefiboṣeti àwọn ọmọkùnrin márààrún ti Merabu, ọmọbìnrin Saulu, àwọn tí ó bí fún Adrieli ọmọ Barsillai ará Mehola. 9 Ó sì fi wọ́n lé àwọn ará Gibeah lọ́wọ́, wọ́n sì so wọ́n rọ̀ lórí òkè níwájú Olúwa: àwọn méjèèjì sì ṣubú lẹ́ẹ̀kan, a sì pa wọ́n ní ìgbà ìkórè, ní ìbẹ̀rẹ̀, ìkórè ọkà barle.
10 Rispa ọmọbìnrin Aiah sì mú aṣọ ọ̀fọ̀ kan, ó sì tẹ́ fún ará rẹ̀ lórí àpáta ní ìbẹ̀rẹ̀ ìkórè, títí omi fi dà sí wọn lára láti ọ̀run wá, kò sì jẹ́ kí àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run bà lé wọn lọ́sàn, tàbí àwọn ẹranko igbó lóru. 11 A sì ro èyí, tí Rispa ọmọbìnrin Aiah obìnrin Saulu ṣe, fún Dafidi. 12 Dafidi sì lọ ó sì kó egungun Saulu, àti egungun Jonatani ọmọ rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọkùnrin Jabesi Gileadi, àwọn tí ó jí wọn kúrò ní ìta Beti-Ṣani, níbi tí àwọn Filistini gbé so wọ́n rọ̀, nígbà tí àwọn Filistini pa Saulu ní Gilboa. 13 Ó sì mú egungun Saulu àti egungun Jonatani ọmọ rẹ̀ láti ibẹ̀ náà wá; wọ́n sì kó egungun àwọn tí a ti so rọ̀ jọ.
14 Wọ́n sì sin egungun Saulu àti ti Jonatani ọmọ rẹ̀ ní ilé Benjamini, ní Ṣela, nínú ibojì Kiṣi baba rẹ̀: wọ́n sì ṣe gbogbo èyí tí ọba paláṣẹ: lẹ́yìn èyí ni Ọlọ́run si gba ẹ̀bẹ̀ nítorí ilẹ̀ náà.
Ìṣẹ́gun lórí Filistini
15 Ogun sì tún wà láàrín àwọn Filistini àti Israẹli; Dafidi sì sọ̀kalẹ̀, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, ó sì bá àwọn Filistini jà: ó sì rẹ Dafidi. 16 Iṣbi-Benobu sì jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn Rafa, ẹni tí ọ̀kọ̀ rẹ̀ wọn ọ̀ọ́dúnrún ṣékélì idẹ, ó sì sán idà tuntun, ó sì gbèrò láti pa Dafidi. 17 Ṣùgbọ́n Abiṣai ọmọ Seruiah ràn án lọ́wọ́, ó sì kọlu Filistini náà, ó sì pa á, Nígbà náà ni àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì búra fún un pé, “Ìwọ kì yóò sì tún bá wa jáde lọ sí ibi ìjà mọ́ kí ìwọ má ṣe pa iná Israẹli.”
18 (A)Lẹ́yìn èyí, ìjà kan sì tún wà láàrín àwọn Israẹli àti àwọn Filistini ní Gobu: nígbà náà ni Sibekai ará Huṣati pa Safu, ẹni tí í ṣe ọ̀kan nínú àwọn Rafa.
19 Ìjà kan sì tún wà ní Gobu láàrín àwọn Israẹli àti àwọn Filistini, Elhanani ọmọ Jairi ará Bẹtilẹhẹmu sì pa arákùnrin Goliati ará Gitti, ẹni tí ọ̀pá ọ̀kọ̀ rẹ̀ dàbí ìdábùú apásá ìhunṣọ.
20 Ìjà kan sì tún wà ní Gati, ọkùnrin kan sì wà tí ó ga púpọ̀, ó sì ní ìka mẹ́fà ní ọwọ́ kan, àti ọmọ ẹsẹ̀ mẹ́fà ní ẹsẹ̀ kan, àpapọ̀ rẹ̀ sì jẹ́ mẹ́rìnlélógún; a sì bí òun náà ní Rafa. 21 Nígbà tí òun sì pe Israẹli ní ìjà. Jonatani ọmọ Ṣimea arákùnrin Dafidi sì pa á.
22 Àwọn mẹ́rẹ̀ẹ̀rin wọ̀nyí ni ìran Rafa ní Gati, wọ́n sì ti ọwọ́ Dafidi ṣubú àti ọwọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
Orin ìyìn Dafidi
22 Dafidi sì kọ ọ̀rọ̀ orin yìí sí Olúwa ní ọjọ́ tí Olúwa gbà á kúrò lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀, àti kúrò lọ́wọ́ Saulu. 2 (B)Ó sì wí pé:
“Olúwa ni àpáta mi, àti Olùgbàlà mi;
3 Ọlọ́run mi, àpáta mi, nínú ẹni tí èmi ní ààbò,
àti ìwo ìgbàlà mi, ibi ìsádi gíga mi.
Àti ibi ìlùmọ̀ mi, Olùgbàlà mi;
ìwọ ni ó ti gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìwà ipá.
4 “Èmi ké pe Olúwa, tí ó yẹ láti máa yìn,
ó sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi.
5 Nígbà tí ìbìlù ìrora ikú yí mi káàkiri;
tí àwọn ìṣàn ènìyàn búburú dẹ́rùbà mí.
6 Ọ̀já isà òkú yí mi káàkiri;
ìkẹ́kùn ikú dojúkọ mí.
7 “Nínú ìpọ́njú mi, èmi ké pé Olúwa,
èmi sì gbé ohùn mi sókè sí Ọlọ́run mi.
Ó sí gbóhùn mi láti tẹmpili rẹ̀
igbe mí wọ etí rẹ̀.
8 Ilẹ̀ sì mì, ó sì wárìrì;
ìpìlẹ̀ ọ̀run wárìrì,
ó sì mì, nítorí tí ó bínú.
9 Èéfín ti ihò imú rẹ̀ jáde wá;
Iná ajónirun ti ẹnu rẹ̀ jáde wá,
ẹ̀yin iná bú jáde láti inú rẹ̀.
10 Ó tẹ orí ọ̀run ba pẹ̀lú, ó sì sọ̀kalẹ̀;
òkùnkùn biribiri sì ń bẹ ní àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ̀.
11 Ó sì gun orí kérúbù, ó sì fò:
a sì rí i lórí ìyẹ́ afẹ́fẹ́.
12 Ó sì fi òkùnkùn ṣe ibùjókòó yí ara rẹ̀, àti àgbájọ omi,
àní ìṣúdudu ìkùùkuu àwọ̀ sánmọ̀.
13 Nípasẹ̀ ìmọ́lẹ̀ iwájú rẹ̀
ẹ̀yín iná ràn.
14 Olúwa sán àrá láti ọ̀run wá,
Ọ̀gá-ògo jùlọ sì fọhùn rẹ̀.
15 Ó sì ta ọfà, ó sì tú wọn ká;
ó kọ mànàmànà, ó sì ṣẹ́ wọn.
16 Ìṣàn ibú Òkun sì fi ara hàn,
ìpìlẹ̀ ayé fi ara hàn,
nípa ìbáwí Olúwa,
nípa fífún èémí ihò imú rẹ̀.
17 “Ó ránṣẹ́ láti òkè wá, ó mú mi;
ó fà mí jáde láti inú omi ńlá wá.
18 Ó gbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá mi alágbára,
lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi: nítorí pé wọ́n lágbára jù mí lọ.
19 Wọ́n wá láti borí mi lọ́jọ́ ìpọ́njú mi:
ṣùgbọ́n Olúwa ni aláfẹ̀yìntì mi.
20 Ó sì mú mi wá sí ààyè ńlá:
ó gbà mi, nítorí tí inú rẹ̀ dún sí mi.
21 “Olúwa sán án fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi;
ó sì san án fún mi gẹ́gẹ́ bí mímọ́ ọwọ́ mi.
22 Nítorí pé èmi pa ọ̀nà Olúwa mọ́,
èmi kò sì fi ìwà búburú yapa kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run mi.
23 Nítorí pé gbogbo ìdájọ́ rẹ̀ ni ó wà níwájú mi;
àti ní ti òfin rẹ̀, èmi kò sì yapa kúrò nínú wọn.
24 Èmi sì wà nínú ìwà títọ́ sí í,
èmi sì pa ara mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi.
25 Olúwa sì san fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi,
gẹ́gẹ́ bí ìwà mímọ́ mi níwájú rẹ̀.
26 “Fún aláàánú ni ìwọ ó fi ara rẹ̀ hàn ni aláàánú,
àti fún ẹni ìdúró ṣinṣin ní òdodo ni ìwọ ó fi ara rẹ hàn ní ìdúró ṣinṣin ní òdodo.
27 Fún onínú funfun ni ìwọ fi ara rẹ hàn ní funfun;
àti fún ẹni wíwọ́ ni ìwọ ó fi ara rẹ hàn ní wíwọ́.
28 Àwọn ènìyàn tí ó wà nínú ìyà ni ìwọ ó sì gbàlà;
ṣùgbọ́n ojú rẹ wà lára àwọn agbéraga, láti rẹ̀ wọ́n sílẹ̀.
29 Nítorí ìwọ ni ìmọ́lẹ̀ mi, Olúwa;
Olúwa yóò sì sọ òkùnkùn mi di ìmọ́lẹ̀.
30 Bẹ́ẹ̀ ni nítorí nípa rẹ̀ ni èmi ti la àárín ogun kọjá;
nípa Ọlọ́run mi èmi ti fo odi kan.
31 “Ọlọ́run yìí, pípé ni ọ̀nà rẹ̀;
ọ̀rọ̀ Olúwa ni a ti dánwò.
Òun sì ni asà fún gbogbo àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé e.
32 Nítorí ta ni Ọlọ́run, bí kò ṣe Olúwa?
Ta ni àpáta, bí kò ṣe Ọlọ́run wa.
33 Ọlọ́run alágbára ni ó fún mi ní agbára,
ó sì sọ ọ̀nà mi di títọ́.
34 Ó ṣe ẹsẹ̀ mi bí ẹsẹ̀ abo àgbọ̀nrín;
ó sì mú mi dúró ní ibi gíga mi.
35 Ó kọ́ ọwọ́ mi ní ogun jíjà;
tó bẹ́ẹ̀ tí apá mi fa ọrun idẹ.
36 Ìwọ sì ti fún mi ní asà
ìgbàlà rẹ̀, ìrẹ̀lẹ̀ rẹ̀ sì ti sọ mí di ńlá.
37 Ìwọ sì sọ ìtẹ̀lẹ̀ di ńlá ní abẹ́ mi;
tó bẹ́ẹ̀ tí ẹsẹ̀ mi kò fi yọ̀.
38 “Èmi ti lépa àwọn ọ̀tá mi, èmi sì ti run wọ́n,
èmi kò pẹ̀yìndà títí èmi fi run wọ́n.
39 Èmi ti pa wọ́n run, èmi sì ti fọ́ wọn,
wọn kò sì le dìde mọ́: wọ́n ṣubú lábẹ́ mi.
40 Ìwọ sì ti fi agbára dì mí ní àmùrè fún ìjà;
àwọn tí ó ti dìde sí mi ni ìwọ sì ti tẹ̀ lórí ba fún mi.
41 Ìwọ sì mú àwọn ọ̀tá mi pẹ̀yìndà fún mi,
èmi ó sì pa àwọn tí ó kórìíra mi run.
42 Wọ́n wò, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan láti gbà wọ́n;
wọ́n wo Olúwa, ṣùgbọ́n kò dá àwọn lóhùn.
43 Nígbà náà ni èmi sì gún wọn wẹ́wẹ́ bí erùpẹ̀ ilẹ̀,
èmi sì tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ bí ẹrẹ̀ ìta, èmi sì tẹ́ wọn gbọrọ.
44 “Ìwọ sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìjà àwọn ènìyàn mi,
ìwọ pa mi mọ́ ki èmi lè ṣe olórí àwọn àjèjì orílẹ̀-èdè.
Àwọn ènìyàn tí èmi kò tí mọ̀ yóò máa sìn mí.
45 Àwọn àjèjì wá láti tẹríba fún mi;
bí wọ́n bá ti gbúròó mi, wọ́n á sì gbọ́ tèmi.
46 Àyà yóò pá àwọn àlejò,
wọ́n ó sì fi ìbẹ̀rù sá kúrò níbi kọ́lọ́fín wọn.
47 “Olúwa ń bẹ́; olùbùkún sì ni àpáta mi!
Gbígbéga sì ni Ọlọ́run àpáta ìgbàlà mi.
48 Ọlọ́run ni ẹni tí ń gbẹ̀san mi,
àti ẹni tí ń rẹ àwọn ènìyàn sílẹ̀ lábẹ́ mi.
49 Àti ẹni tí ó gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi.
Ìwọ sì gbé mi sókè ju àwọn tí ó kórìíra mi lọ;
ìwọ sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn ọkùnrin oníwà ipá.
50 (C)Nítorí náà èmi ó fi ọpẹ́ fún ọ, Olúwa,
láàrín àwọn àjèjì orílẹ̀-èdè: èmi ó sì kọrin sí orúkọ rẹ.
51 “Òun ni ilé ìṣọ́ ìgbàlà fún ọba rẹ̀;
ó sì fi àánú hàn fún ẹni ààmì òróró rẹ̀,
fún Dafidi, àti fún irú-ọmọ rẹ̀ títí láéláé.”
24 (A)Nígbà tí Jesu rí i pé inú rẹ̀ bàjẹ́ gidigidi, ó wí pé, “Yóò ti ṣòro tó fún àwọn tí ó ní ọrọ̀ láti wọ ìjọba Ọlọ́run! 25 Nítorí ó rọrùn fún ìbákasẹ láti gba ojú abẹ́rẹ́ wọlé jù fún ọlọ́rọ̀ láti wọ ìjọba Ọlọ́run lọ.”
26 Àwọn tí ó sì gbọ́ wí pé, “Ǹjẹ́ ta ni ó ha lè là?”
27 (B)Ó sì wí pé, “Ohun tí ó ṣòro lọ́dọ̀ ènìyàn kò ṣòro lọ́dọ̀ Ọlọ́run.”
28 (C)Peteru sì wí pé, “Sá wò ó, àwa ti fi ilé wa sílẹ̀, a sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn!”
29 Ó sì wí fún wọn pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, kò sí ẹni tí ó fi ilé, tàbí aya, tàbí ará, tàbí òbí, tàbí ọmọ sílẹ̀, nítorí ìjọba Ọlọ́run, 30 Tí kì yóò gba ìlọ́po púpọ̀ sí i ní ayé yìí, àti ní ayé tí ń bọ̀ ìyè àìnípẹ̀kun.”
Jesu tún sọ nípa ikú rẹ̀
31 (D)Nígbà náà ni ó pe àwọn méjìlá sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì wí fún wọn pé, “Sá wò ó, àwa ń gòkè lọ sí Jerusalẹmu, a ó sì mú ohun gbogbo ṣẹ, tí a ti kọ láti ọwọ́ àwọn wòlíì, nítorí Ọmọ Ènìyàn. 32 Nítorí tí a ó fi lé àwọn aláìkọlà lọ́wọ́, a ó fi ṣe ẹlẹ́yà, a ó sì fi ṣe ẹ̀sín, a ó sì tutọ́ sí i lára. 33 Wọn ó sì nà án, wọn ó sì pa á: ní ọjọ́ kẹta yóò sì jíǹde.”
34 Ọ̀kan nínú nǹkan wọ̀nyí kò sì yé wọn: ọ̀rọ̀ yìí sì pamọ́ fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì mọ ohun tí a wí.
Afọ́jú alágbe gba ìwòsàn
35 (E)Bí ó ti súnmọ́ Jeriko, afọ́jú kan jókòó lẹ́bàá ọ̀nà ó ń ṣagbe: 36 Nígbà tí ó gbọ́ tí ọ̀pọ̀ ń kọjá lọ, ó béèrè pé, kín ni ìtumọ̀ èyí. 37 Wọ́n sì wí fún un pé, “Jesu ti Nasareti ni ó ń kọjá lọ.”
38 Ó sì kígbe pé, “Jesu, ìwọ ọmọ Dafidi, ṣàánú fún mi!”
39 Àwọn tí ń lọ níwájú bá a wí, pé, kí ó pa ẹnu rẹ̀ mọ́: ṣùgbọ́n òun sì kígbe sókè sí í pé, “Ìwọ Ọmọ Dafidi, ṣàánú fún mi!”
40 Jesu sì dúró, ó ní, kí á mú un tọ òun wá nígbà tí ó sì súnmọ́ ọn, ó bi í, 41 Wí pé, “Kí ni ìwọ ń fẹ́ kí èmi ṣe fún ọ?”
Ó sì wí pé, “Olúwa jẹ́ kí èmi ríran.”
42 (F)Jesu sì wí fún un pé, “Ríran; ìgbàgbọ́ rẹ mú ọ láradá.” 43 Lójúkan náà ó sì ríran, ó sì ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, ó sì ń yin Ọlọ́run lógo àti gbogbo ènìyàn nígbà tí wọ́n rí i, wọ́n fi ìyìn fún Ọlọ́run.
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.