Print Page Options
Previous Prev Day Next DayNext

Old/New Testament

Each day includes a passage from both the Old Testament and New Testament.
Duration: 365 days
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Version
Amosi 4-6

Israẹli kò yípadà sí Ọlọ́run

Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí, ẹ̀yin màlúù Baṣani lórí òkè Samaria,
    ẹ̀yin obìnrin tí ó ń ni tálákà lára,
    tí ó ń tẹ aláìní mọ́lẹ̀, tí ó wí fún ọkọ rẹ̀, “Gbé wá kí a sì mu!”
Olúwa Olódùmarè ti fi ìwà mímọ́ rẹ̀ búra:
    “Àkókò náà yóò dé nítòótọ́
nígbà tí a ó fi ìwọ̀ mú un yín lọ,
    ẹni tí ó kẹ́yìn pẹ̀lú ìwọ̀ ẹja.
Ẹni kọ̀ọ̀kan yín yóò jáde lọ
    gba àárín odi yíya
    a ó sì lé e yín sí Harmoni,”
    ni Olúwa wí.
“Ẹ lọ sí Beteli láti dẹ́ṣẹ̀;
    ẹ lọ sí Gilgali kí ẹ sì dẹ́ṣẹ̀ sí i.
Ẹ mú ẹbọ sísun yín láràárọ̀ wá,
    ìdámẹ́wàá yín ní ọdọọdún mẹ́ta.
Kí ẹ mú ọ̀rẹ́ ìdúpẹ́ ìyẹ̀fun ìwúkàrà ti a sun
    kí ẹ sì mú ọrẹ àtinúwá
lọ fi wọ́n yangàn, ẹ̀yin ènìyàn Israẹli,
    nítorí èyí ni ẹ fẹ́ láti ṣe,”
    ni Olúwa Olódùmarè wí.

“Èmi fún un yín ní mímọ́ eyín ní gbogbo ìlú yín,
    àti àìní oúnjẹ ní gbogbo ibùgbé yín,
    síbẹ̀, ẹ̀yin kò yípadà sọ́dọ̀ mi,”
    ni Olúwa wí.

“Àti pẹ̀lú mo mú òjò dúró
    nígbà tí ìkórè ku oṣù mẹ́ta.
Mo rán òjò sí ibùgbé kan
    ṣùgbọ́n kò rọ̀ sí ìlú mìíràn.
Oko kan ní òjò;
    àwọn mìíràn kò ní ó sì gbẹ.
Àwọn ènìyàn ń rìn láti ìlú kan sí ìlú mìíràn fún omi
    wọn kò rí mu tẹ́ wọn lọ́rùn,
    síbẹ̀ ẹ̀yin kò padà sí ọ̀dọ̀ mi,”
    ni Olúwa wí.

“Lọ́pọ̀ ìgbà ni mo kọlu ọgbà àti ọgbà àjàrà yín
    mo fi ìrẹ̀dànù àti ìmúwòdù lù wọ́n.
Eṣú sì jẹ igi ọ̀pọ̀tọ́ àti igi olifi yín,
    síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,”
    ni Olúwa wí.

10 “Mo rán àjàkálẹ̀-ààrùn sí i yín
    bí mo ti ṣe sí Ejibiti.
Mo fi idà pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín.
    Pẹ̀lú àwọn ẹṣin tí a kó ní ìgbèkùn.
Mo kún imú yín fún òórùn ibùdó yín,
    síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,”
    ni Olúwa wí.

11 “Mo ti bì ṣubú nínú yín,
    bí Ọlọ́run ti bi Sodomu àti Gomorra ṣubú
ẹ̀yin sì dàbí ògúnná tí a fa yọ kúrò nínú iná,
    síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,”
    ni Olúwa wí.

12 “Nítorí náà, èyí ni ohun tí èmi yóò ṣe sí i yín, Israẹli,
    àti nítorí tí èmi ó ṣe èyí sí i yín,
    ẹ múra láti pàdé Ọlọ́run yín, ẹ̀yin Israẹli.”

13 Ẹni tí ó dá àwọn òkè
    tí ó dá afẹ́fẹ́
    tí ó sì fi èrò rẹ̀ hàn sí ènìyàn,
ẹni tí ó yípadà sí òkùnkùn
    tí ó sì tẹ ibi gíga ayé.
    Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.

Wò mí kí o sì yè

Gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí, ìwọ ilé Israẹli, ìpohùnréré ẹkún tí mo ṣe nípa rẹ:

“Wúńdíá Israẹli ṣubú
    láì kò sì le padà dìde
ó di ẹni ìkọ̀tì ní ilẹ̀ rẹ̀
    kò sí ẹni tí yóò gbé e dìde.”

Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí:

“Ìlú tí ẹgbẹ̀rún alágbára ti jáde,
    yóò dín ku ọgọ́ọ̀rún ní Israẹli.
Ìlú tí ọgọ́ọ̀rún alàgbà ti jáde
    yóò ṣẹ́kù ẹni mẹ́wàá.”

Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún ilé Israẹli:

“Wá mi kí o sì yè;
    Ẹ má ṣe wá Beteli,
Ẹ má ṣe lọ sí Gilgali
    Ẹ má ṣe rìnrìn àjò lọ sí Beerṣeba.
Nítorí dájúdájú a ó kó Gilgali ní ìgbèkùn
    A ó sì sọ Beteli di asán.”
Ẹ wá Olúwa, ẹ̀yin yóò sì yè,
    kí ó má ba à gbilẹ̀ bí iná ní Josẹfu
a sì jó o run
    Beteli kò sì ní rí ẹni tí yóò bu omi pa á.

Ẹ̀yin tí ẹ̀ sọ òdodo di ìkorò
    tí ẹ sì gbé olódodo ṣánlẹ̀.

Ẹni tí ó dá ìràwọ̀ Pleiadesi àti Orioni
    ẹni tí ó sọ òru dúdú di òwúrọ̀
    tí ó sọ ọjọ́ dúdú di ìmọ́lẹ̀
ẹni tí ó wọ́ omi Òkun jọ pọ̀
    tí ó sì rọ̀ wọ́n sí orí ilẹ̀
    Olúwa ni orúkọ rẹ̀,
Ó fọ́n ìparun sí ìlú olódi
    tí ó sì sọ àwọn ibùgbé àwọn ọmọ-aládé di ahoro.

10 Ìwọ kórìíra ẹni tí ń bá ni wí ní ẹnu ibodè
    ó sì ń pẹ̀gàn ẹni tí ń sọ òtítọ́.

11 Ìwọ ń tẹ tálákà mọ́lẹ̀
    o ń fi ipá gba ọkà lọ́wọ́ wọn
Nítorí náà, ìwọ ti fi òkúta tí a gbẹ́ kọ́lé
    ṣùgbọ́n ẹ kò sì ní gbé inú wọn
Nítòótọ́ ìwọ ti gbin ọgbà àjàrà tí ó lẹ́wà.
    Ìwọ kò ní mu wáìnì inú wọn
12 Nítorí mo mọ iye àìṣedéédéé rẹ
    mo sì mọ bí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ tí tóbi tó.

Ìwọ ni olódodo lára, ìwọ sì ń gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀
    o sì ń fi òtítọ́ du tálákà ní ilé ẹjọ́
13 Àwọn ọlọ́gbọ́n máa ń dákẹ́ jẹ́ẹ́ ní àkókò wọ̀nyí,
    nítorí búburú ni gbogbo ọjọ́.

14 Wá rere, má ṣe wá búburú
    kí ìwọ ba à le yè
Nígbà náà ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun yóò wà pẹ̀lú rẹ.
    Òun yóò sì wà pẹ̀lú rẹ bí ìwọ ṣe wí
15 Kórìíra búburú kí o sì fẹ́ rere
    dúró ní orí òtítọ́ ní ilé ẹjọ́
bóyá Olúwa Ọlọ́run alágbára
    yóò ṣíjú àánú wo ọmọ Josẹfu tó ṣẹ́kù.

16 Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun wí:

“Ẹkún yóò wà ní àwọn òpópónà
    igbe ìnira yóò sì wà ní àwọn gbàgede ìlú
A ó kó àwọn àgbẹ̀ jọ láti sọkún
    àti àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ láti pohùnréré ẹkún
17 Ìpohùnréré ẹkún yóò wà ní gbogbo ọgbà àjàrà
    Nítorí èmi yóò la àárín yín kọjá,”
    ni Olúwa wí.

Ọjọ́ Olúwa

18 Ègbé ni fún ìwọ tí ó pẹ́
    nítorí ọjọ́ Olúwa
kí ni ìwọ fi pẹ́ fún ọjọ́ Olúwa?
    Ìmọ́lẹ̀ yóò di òkùnkùn ní ojú ọjọ́
19 Gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí ó sá fún kìnnìún,
    tí ó padà wá bọ́ sí ẹnu àmọ̀tẹ́kùn.
Yóò dàbí ẹni tí ó wọ ilé rẹ̀ lọ
    tí ó sinmi lé ògiri ilé rẹ̀
    tí ejò sì bù ú ṣán.
20 Ǹjẹ́ ọjọ́ Olúwa kò ha ní ṣókùnkùn dípò kí ó ní ìmọ́lẹ̀?
    Tí yóò sì ṣókùnkùn dúdú láìsí ìmọ́lẹ̀ kankan níbẹ̀.

21 “Mo kórìíra, mo kẹ́gàn àwọn àsè ẹ̀sìn in yín
    Èmi kò sì ní inú dídùn sí àpéjọ yín
22 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ mú ẹbọ sísun àti ọrẹ ọkà wá
    Èmi kò ní tẹ́wọ́ gbà wọ́n
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ mú àṣàyàn ọrẹ àlàáfíà wá.
    Èmi kò ní náání wọn.
23 Ẹ gbé ariwo orin yín sẹ́yìn
    Èmi kò ní fetísí ohun èlò orin yín.
24 Jẹ́ kí òtítọ́ sàn bí odò
    àti òdodo bí ìsun tí kò lé è gbẹ!

25 (A)“Àbí ẹ̀yin mú ẹbọ àti ọrẹ tọ̀ mí wá
    ní ogójì ọdún ní aginjù ìwọ ilé Israẹli?
26 Ẹ̀yin ti gbé ibi ìrúbọ àwọn ọba yín sókè
    ibùgbé àwọn òrìṣà yín
    àní, ti àwọn òrìṣà yín tí ó níyì jùlọ,
    èyí tí ẹ̀yin fi ọwọ́ ara yín ṣe.
27 Nítorí náà èmi yóò rán an yín lọ sí ìgbèkùn ní ìkọjá Damasku,”
    ni Olúwa wí, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Ọlọ́run alágbára.

Ègbé ni fún àwọn tí ara rọ̀

Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ará rọ̀ ní Sioni
    àti ẹ̀yin tí ẹ wà ní abẹ́ ààbò ní òkè Samaria
àti ẹ̀yin olókìkí orílẹ̀-èdè
    tí ẹ̀yin ènìyàn Israẹli máa ń tọ̀ ọ́ wá
Ẹ lọ Kalne kí ẹ lọ wò ó
    kí ẹ sí tí ibẹ̀ lọ sí Hamati ìlú ńlá a nì.
    Kí ẹ sì tún sọ̀kalẹ̀ lọ Gati ní ilẹ̀ Filistini
Ǹjẹ́ wọ́n ha dára ju ìpínlẹ̀ yín méjèèjì lọ?
    Ǹjẹ́ a ha rí ilẹ̀ tó tóbi ju tiyín lọ bí?
Ẹ̀yin sún ọjọ́ ibi síwájú,
    ẹ sì mú ìjọba òǹrorò súnmọ́ tòsí
Ẹ̀yin sùn lé ibùsùn tí a fi eyín erin ṣe
    ẹ sì tẹ́ ara sílẹ̀ ni orí àwọn ibùsùn
ẹyin pa èyí tí o dára nínú àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn yín jẹ
    ẹ sì ń pa àwọn ọ̀dọ́ màlúù láàrín agbo wọn jẹ
Ẹ̀yin ń lo ohun èlò orin bí i Dafidi
    ẹ sì ń ṣe àwọn àpilẹ̀rọ àwọn ohun èlò orin
Ẹ̀yin mu wáìnì ẹ̀kún ọpọ́n kan
    àti ìkunra tí o dára jùlọ
    ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò káàánú ilé Josẹfu tí ó di ahoro
Nítorí náà, àwọn ni yóò lọ sí ìgbèkùn
    pẹ̀lú àwọn tí ó ti kó lọ sí ìgbèkùn
àsè àwọn tí ń ṣe àṣelékè ni a ó mú kúrò.

Olúwa Kórìíra Ìgbéraga Ọmọ Israẹli

Olúwa Olódùmarè ti búra fúnrarẹ̀, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun sì ti wí pé:

“Mo kórìíra ìgbéraga Jakọbu
    n kò sì ní inú dídùn sí odi alágbára rẹ̀
Èmi yóò sì fa ìlú náà lé wọn lọ́wọ́
    àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀.”

Bí Ọkùnrin mẹ́wàá bá ṣẹ́kù nínú ilé kan, àwọn náà yóò kú 10 Bí ẹbí tí ó yẹ kí ó gbé òkú wọn jáde fún sínsin bá wọlé, bí o ba sì béèrè pé ǹjẹ́ ẹnìkan wa tí ó fi ara pamọ́ níbẹ̀, “Ǹjẹ́ ẹnìkankan wà lọ́dọ̀ yín?” tí ó bá sì dáhùn wí pé, “Rárá,” nígbà náà ni yóò wí pé, “Pa ẹnu rẹ mọ́ àwa kò gbọdọ̀ dárúkọ Olúwa.”

11 Nítorí Olúwa tí pa àṣẹ náà,
    Òun yóò sì wó ilé ńlá náà lulẹ̀ túútúú
    Àti àwọn ilé kéékèèkéé sí wẹ́wẹ́.

12 Ǹjẹ́ ẹṣin a máa sáré lórí àpáta bí?
    Ǹjẹ́ ènìyàn a máa fi akọ màlúù kọ ilẹ̀ níbẹ̀?
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti yí òtítọ́ padà sí májèlé
    ẹ sì ti sọ èso òdodo di ìkorò.
13 Ẹ̀yin yọ̀ torí ìṣẹ́gun lórí Lo-Debari
    Ẹ̀yin sì wí pé, “Ṣé kì í ṣe agbára wa ni àwa fi gba Karnaimu?”

14 Nítorí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun wí pé,
    “Èmi yóò gbé orílẹ̀-èdè kan dìde sí ọ ìwọ Israẹli,
wọn yóò pọ́n yín lójú ní gbogbo ọ̀nà,
    láti Lebo-Hamati, títí dé pẹ̀tẹ́lẹ̀ Arabah.”

Ìfihàn 7

Ọ̀kẹ́ méje-olé-ẹgbàá-méjì èdìdì ìwé

(A)Lẹ́yìn èyí ni mo rí angẹli mẹ́rin dúró ní igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ayé, wọ́n di afẹ́fẹ́ mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ayé mú, kí ó má ṣe fẹ́ sórí ilẹ̀, tàbí sórí Òkun, tàbí sára igikígi. Mo sì rí angẹli mìíràn tí ó ń ti ìhà ìlà-oòrùn gòkè wá, ti òun ti èdìdì Ọlọ́run alààyè lọ́wọ́ rẹ. Ó sì kígbe ní ohùn rara sí àwọn angẹli mẹ́rin náà tí a fi fún un láti pa ayé, àti Òkun, lára, (B)wí pé, “Ẹ má ṣe pa ayé, tàbí Òkun, tàbí igi lára, títí àwa ó fi fi èdìdì sàmì sí àwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run wa ní iwájú wọn.” Mo sì gbọ́ iye àwọn tí a fi èdìdì sàmì si: Àwọn tí a sàmì sí jẹ́ ọ̀kẹ́ méje ó-lé-ẹgbàajì láti inú gbogbo ẹ̀yà àwọn ọmọ Israẹli wá.

Láti inú ẹ̀yà Juda a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá-mẹ́fà (12,000).

Láti inú ẹ̀yà Reubeni a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá-mẹ́fà (12,000).

Láti inú ẹ̀yà Gadi a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá-mẹ́fà (12,000).

Láti inú ẹ̀yà Aṣeri a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá-mẹ́fà (12,000).

Láti inú ẹ̀yà Naftali a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá-mẹ́fà (12,000).

Láti inú ẹ̀yà Manase a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá-mẹ́fà (12,000).

Láti inú ẹ̀yà Simeoni a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá-mẹ́fà (12,000).

Láti inú ẹ̀yà Lefi a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá-mẹ́fà (12,000).

Láti inú ẹ̀yà Isakari a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá-mẹ́fà (12,000).

Láti inú ẹ̀yà Sebuluni, a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá-mẹ́fà (12,000).

Láti inú ẹ̀yà Josẹfu a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá-mẹ́fà (12,000).

Láti inú ẹ̀yà Benjamini a fi èdìdì sàmì sí ẹgbàá-mẹ́fà (12,000).

Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn nínú ẹ̀wù funfun

Lẹ́yìn náà, mo ri, sì kíyèsi i, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn tí ẹnikẹ́ni kò lè kà, láti inú orílẹ̀-èdè gbogbo, àti ẹ̀yà, àti ènìyàn, àti láti inú èdè gbogbo wá, wọn dúró níwájú ìtẹ́, àti níwájú Ọ̀dọ́-Àgùntàn náà, a wọ̀ wọ́n ni aṣọ funfun, imọ̀ ọ̀pẹ si ń bẹ ni ọwọ́ wọn. 10 Wọ́n sì kígbe ní ohùn rara, wí pé:

“Ìgbàlà ni ti Ọlọ́run wá
tí o jókòó lórí ìtẹ́,
àti ti Ọ̀dọ́-àgùntàn!”

11 Gbogbo àwọn angẹli sì dúró yí ìtẹ́ náà ká, àti yí àwọn àgbà àti àwọn ẹ̀dá alààyè mẹ́rin náà ká, wọn wólẹ̀ wọn si dojúbolẹ̀ níwájú ìtẹ́ náà wọ́n sì sin Ọlọ́run. 12 Wí pe:

“Àmín!
Ìbùkún, àti ògo,
àti ọgbọ́n, àti ọpẹ́, àti ọlá,
àti agbára àti ipá fún Ọlọ́run wa láé àti láéláé!
Àmín!”

13 Ọ̀kan nínú àwọn àgbà náà si dáhùn, ó bi mí pé, “Ta ni àwọn wọ̀nyí tí a wọ ni aṣọ funfun? Níbo ni wọn sì ti wá?”

14 (C)Mo sì wí fún un pé, “Olúwa mi, ìwọ ni o lè mọ̀.”

Ó sì wí fún mí pé, “Àwọn wọ̀nyí ni o jáde láti inú ìpọ́njú ńlá, wọ́n sì fọ aṣọ wọ́n, wọ́n sì sọ wọ́n di funfun nínú ẹ̀jẹ̀ Ọ̀dọ́-àgùntàn náà. 15 Nítorí náà ni,

“wọn ṣe ń bẹ níwájú ìtẹ́ Ọlọ́run,
    tí wọn sì ń sìn ín, lọ́sàn àti lóru nínú tẹmpili rẹ̀;
ẹni tí o jókòó lórí ìtẹ́ náà yóò si ṣíji bò wọn.
16 (D)Ebi kì yóò pa wọn mọ́,
    bẹ́ẹ̀ ni òùngbẹ kì yóò gbẹ́ wọ́n mọ́;
bẹ́ẹ̀ ni oòrùn kì yóò pa wọn
    tàbí oorukóoru kan.
17 (E)Nítorí ọ̀dọ́-àgùntàn tí ń bẹ ni àárín ìtẹ́ náà ni yóò máa ṣe olùṣọ́-àgùntàn wọn,
    ‘tí yóò sì máa ṣe amọ̀nà wọn sí ibi orísun omi ìyè:’
‘Ọlọ́run yóò sì nu omijé gbogbo nù kúrò ni ojú wọn.’ ”

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)

Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.