Print Page Options
Previous Prev Day Next DayNext

Chronological

Read the Bible in the chronological order in which its stories and events occurred.
Duration: 365 days
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Version
Isaiah 64-66

64 Ìwọ ìbá fa ọ̀run ya kí o sì sọ̀kalẹ̀ wá,
    tí àwọn òkè ńlá yóò fi wárìrì níwájú rẹ!
Gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí iná mú ẹ̀ka igi jó
    tí ó sì mú kí omi ó hó,
sọ̀kalẹ̀ wá kí orúkọ rẹ le di mí mọ̀ fún àwọn ọ̀tá rẹ
    kí o sì jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè kí ó wárìrì níwájú rẹ!
Nítorí nígbà tí o bá ṣe àwọn ohun ẹ̀rù tí àwa kò nírètí,
    o sọ̀kalẹ̀ wá, àwọn òkè ńlá sì wárìrì níwájú rẹ̀.
(A)Láti ìgbà àtijọ́ kò sí ẹni tí ó gbọ́ rí
    kò sí etí kan tí ó gbọ́ ọ,
kò sí ojú tí ó tí ì rí Ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn rẹ,
    tí ó máa ń ṣe nǹkan lórúkọ àwọn tí ó dúró dè é.
Ìwọ a máa wá fún ìrànlọ́wọ́ àwọn tí wọn
    ń fi ayọ̀ ṣe ohun tó tọ́,
tí ó rántí ọ̀nà rẹ.
    Ṣùgbọ́n nígbà tí a bẹ̀rẹ̀ sí dẹ́ṣẹ̀ sí wọn,
inú bí ọ.
    Báwo ni a ó ṣe gbà wá là?
Gbogbo wa ti dàbí ẹnìkan tí ó jẹ́ aláìmọ́,
    gbogbo òdodo wa sì dàbí èkísà ẹlẹ́gbin;
gbogbo wa kákò bí ewé,
    àti bí afẹ́fẹ́, ẹ̀ṣẹ̀ wa ti gbá wa lọ kúrò.
Ẹnikẹ́ni kò pe orúkọ rẹ
    tàbí kí ó gbìyànjú láti dì ẹ́ mú;
nítorí ìwọ ti fi ojú rẹ pamọ́ fún wa
    ó sì jẹ́ kí àwa ṣòfò dànù nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa.

Síbẹ̀síbẹ̀, Olúwa, ìwọ ni Baba wa.
    Àwa ni amọ̀, ìwọ ni amọ̀kòkò;
    gbogbo wa jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
Má ṣe bínú kọjá ààlà, ìwọ Olúwa:
    Má ṣe rántí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ wa títí láé.
Jọ̀wọ́, bojú wò wá, ni a gbàdúrà,
    nítorí ènìyàn rẹ ni gbogbo wa.
10 Àwọn ìlú mímọ́ rẹ ti di aṣálẹ̀;
    Sioni pàápàá di aṣálẹ̀, Jerusalẹmu di ahoro.
11 Tẹmpili mímọ́ ológo wa, níbi tí àwọn baba wa ti yìn ọ́,
    ni a ti fi iná sun,
    àti ohun gbogbo tí í ṣe ìṣúra wa ti dahoro.
12 Lẹ́yìn gbogbo nǹkan wọ̀nyí, Olúwa, ìwọ
    ó ha sì tún fi ara rẹ pamọ́ bí?
    Ìwọ ó ha dákẹ́ kí o sì fìyà jẹ wá kọjá ààlà bí?

Ìdájọ́ àti ìgbàlà

65 (B)“Èmi fi ara mi hàn fún àwọn tí kò béèrè fún mi;
    Àwọn tí kò wá mi ni wọ́n rí mi.
Sí àwọn orílẹ̀-èdè tí kò pe orúkọ mi,
    Ni èmi wí pé, ‘Èmi nìyìí, Èmi nìyìí.’
Gbogbo ọjọ́ ni mo ti nawọ́ mi síta
    sí àwọn ènìyàn ọlọ́rùn líle,
tí wọn ń rìn lọ́nà tí kò dára,
    tí wọ́n sì gbára lé èrò ara wọn
àwọn ènìyàn tí wọ́n bí mi nínú nígbà gbogbo
    lójú ara mi gan an,
wọ́n ń rú ẹbọ nínú ọgbà
    wọ́n sì ń sun tùràrí lórí i pẹpẹ bíríkì;
wọ́n ń jókòó láàrín ibojì
    wọ́n sì ń lo òru wọn nínú ìṣọ́ ìkọ̀kọ̀;
tí wọ́n ń jẹ ẹran ẹlẹ́dẹ̀,
    tí ìkòkò ọbẹ̀ wọn kún fún ẹran àìmọ́;
tí ó wí pé, ‘Ẹ sún mẹ́yìn; ẹ má wá sọ́dọ̀ mi,
    nítorí mo ti jẹ́ mímọ́ jù fún un yín!’
Àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀ jẹ́ èéfín nínú ihò imú mi
    iná tí ń fi gbogbo ọjọ́ jó.

“Kíyèsi i, a ti kọ ọ́ síwájú mi:
    Èmi kì yóò dákẹ́,
ṣùgbọ́n èmi yóò san án padà lẹ́kùnrẹ́rẹ́;
    Èmi yóò san án padà sí àyà wọn
àwọn ẹ̀ṣẹ̀ yín àti tàwọn baba yín,”
    ni Olúwa wí.
“Nítorí pé wọ́n sun ẹbọ ní orí òkè ńlá
    wọ́n sì ṣe ẹ̀gbin sí mi ní òkè kékeré,
Èmi yóò wọ́n ọ́n sí itan wọn
    ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ẹ̀san ohun gbogbo tí wọ́n ṣe tẹ́lẹ̀.”

Báyìí ni Olúwa wí:

“Gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí oje sì tún wà nínú àpólà àjàrà
    tí àwọn ènìyàn sì wí pé, ‘má ṣe bà á jẹ́,
nítorí ìbùkún ń bẹ nínú rẹ̀,’
    bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣe nítorí ìránṣẹ́ mi;
    Èmi kì yóò pa gbogbo wọn run.
Èmi yóò mú ìrandíran wá láti ìdílé Jakọbu,
    àti láti Juda àwọn tí yóò jogún òkè ńlá mi wọ̀n-ọn-nì;
àwọn àyànfẹ́ ènìyàn mi yóò jogún wọn,
    ibẹ̀ ni àwọn ìránṣẹ́ mi yóò sì gbé.
10 Ṣaroni yóò di pápá oko fún ọ̀wọ́ ẹran,
    àti Àfonífojì Akori yóò di ibi ìsinmi fún agbo ẹran,
    fún àwọn ènìyàn mi tí ó wá mi.

11 “Ṣùgbọ́n fún ẹ̀yin tí ó kọ Olúwa sílẹ̀
    tí ó sì gbàgbé òkè ńlá mímọ́ mi,
tí ó tẹ́ tábìlì fún Gadi
    tí ẹ sì kún abọ́ pẹ̀lú ọtí wáìnì fún àtubọ̀tán,
12 Èmi yóò yà ọ́ sọ́tọ̀ fún idà,
    àti pé ẹ̀yin yóò bẹ̀rẹ̀ mọ́lẹ̀ fún àwọn tí a pa;
nítorí mo pè, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò dáhùn.
    Mo sọ̀rọ̀ ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò tẹ́tí sílẹ̀
Ẹ̀yin ṣe búburú ní ojú mi
    ẹ sì yan ohun tí ó bà mí lọ́kàn jẹ́.”

13 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí:

“Àwọn ìránṣẹ́ mi yóò jẹun;
    ṣùgbọ́n ebi yóò máa pa ẹ̀yin,
àwọn ìránṣẹ́ mi yóò mu,
    ṣùgbọ́n òǹgbẹ yóò máa gbẹ ẹ̀yin;
àwọn ìránṣẹ́ mi yóò ṣe àjọyọ̀,
    ṣùgbọ́n a ó dójútì yin.
14 Àwọn ìránṣẹ́ mi yóò kọrin
    láti inú ayọ̀ ọkàn wọn wá,
ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò kígbe sókè
    láti inú ìrora ọkàn yín
    àti ìpohùnréré ní ìròbìnújẹ́ ọkàn.
15 Ẹ̀yin yóò fi orúkọ yín sílẹ̀
    fún àwọn àyànfẹ́ mi gẹ́gẹ́ bí ègún;
Olúwa Olódùmarè yóò sì pa yín,
    ṣùgbọ́n fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ ni òun
    yóò fún ní orúkọ mìíràn
16 Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbàdúrà ìbùkún ní ilẹ̀ náà
    yóò ṣe é nípasẹ̀ Ọlọ́run òtítọ́;
Ẹni tí ó bá búra ní ilẹ̀ náà
    yóò búra nípasẹ̀ Ọlọ́run òtítọ́.
Nítorí ìyọnu àtijọ́ yóò di ìgbàgbé
    yóò sì fi ara sin kúrò lójú mi.

Àwọn ọrun tuntun àti ayé tuntun

17 “Kíyèsi i, Èmi yóò dá
    àwọn ọ̀run tuntun àti ayé tuntun
A kì yóò rántí ohun àtẹ̀yìnwá mọ́,
    tàbí kí wọn wá sí ọkàn.
18 Ṣùgbọ́n ẹ yọ̀ kí inú yín dùn títí láé
    nínú ohun tí èmi yóò dá,
nítorí èmi yóò dá Jerusalẹmu láti jẹ́ ohun ìdùnnú
    àti àwọn ènìyàn rẹ̀, ohun ayọ̀.
19 Èmi yóò ṣe àjọyọ̀ lórí Jerusalẹmu
    n ó sì ní inú dídùn nínú àwọn ènìyàn mi;
ariwo ẹkún àti igbe
    ni a kì yóò gbọ́ nínú rẹ̀ mọ́.

20 “Títí láé a kì yóò gbọ́ nínú rẹ̀
    ọmọ ọwọ́ tí yóò gbé fún ọjọ́ díẹ̀,
tàbí àgbàlagbà tí kì yóò lo ọjọ́ ayé rẹ̀ tán;
    ẹni tí ó bá kú ní ìwọ̀n ọgọ́rùn-ún
ni a ó pè ní ọ̀dọ́mọdé;
    ẹni tí kò ba le pé ọgọ́rùn-ún kan
    ni a ó pè ní ẹni ìfibú.
21 Wọn yó ò kọ́ ilé, wọn yóò sì gbé nínú wọn
    wọn yóò gbin ọgbà àjàrà, wọn yóò sì jẹ èso wọn.
22 Wọn kì yóò kọ́ ilé fún ẹlòmíràn láti gbé,
    tàbí kí wọn gbìn fún ẹlòmíràn láti jẹ,
Nítorí gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ orí igi kan,
    bẹ́ẹ̀ ní ọjọ́ àwọn ènìyàn mi yóò rí;
àwọn àyànfẹ́ mi yóò jẹ iṣẹ́ ọwọ́
    wọn fún ìgbà pípẹ́.
23 Wọn kì yóò ṣe iṣẹ́ lásán,
    wọn kí yóò bímọ fún wàhálà;
    nítorí wọn yóò jẹ́ àwọn ènìyàn ti Olúwa bùkún fún,
    àwọn àti àwọn ìrandíran wọn pẹ̀lú wọn.
24 Kí wọn tó pè, èmi yóò dáhùn;
    nígbà tí wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ lọ́wọ́, èmi yóò gbọ́.
25 (C)Ìkookò àti ọ̀dọ́-àgùntàn yóò jẹun pọ̀,
    kìnnìún yóò sì jẹ koríko gẹ́gẹ́ bí akọ màlúù,
ṣùgbọ́n erùpẹ̀ ni yóò jẹ́ oúnjẹ ejò.
    Wọn kì yóò pa ni lára tàbí pa ni run
ní gbogbo òkè mímọ́ mi,”
    ni Olúwa wí.

Ìdájọ́ àti ìrètí

66 (D)Báyìí ni Olúwa wí:

“Ọ̀run ni ìtẹ́ mi,
    ayé sì ni àpótí ìtìsẹ̀ mi,
Níbo ni ilé tí ẹ ó kọ́ fún mi wà?
    Níbo ní ibi ìsinmi mi yóò gbé wà?
Kì í ha á ṣe ọwọ́ mi ló tí ṣe nǹkan wọ̀nyí,
    bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì wà?”
    ni Olúwa wí.

“Eléyìí ni ẹni tí mo kà sí:
    ẹni náà tí ó rẹra rẹ̀ sílẹ̀ tí ó sì kẹ́dùn ní ọkàn rẹ̀,
    tí ó sì wárìrì sí ọ̀rọ̀ mi.
Ṣùgbọ́n ẹni tí ó fi akọ màlúù rú ẹbọ
    ó dàbí ẹni tí ó pa ènìyàn kan
àti ẹni tí ó bá fi ọ̀dọ́-àgùntàn kan tọrẹ,
    dàbí ẹni tí ó bẹ́ ajá kan lọ́rùn;
ẹnikẹ́ni tí ó bá fi irúgbìn ìyẹ̀fun tọrẹ
    dàbí ẹni tí ó mú ẹ̀jẹ̀ ẹlẹ́dẹ̀ wá,
ẹni tí ó bá sì sun tùràrí ìrántí,
    dàbí ẹni tí ó súre fún òrìṣà.
Wọ́n ti yan ipa ọ̀nà tì wọ́n,
    ọkàn wọn pẹ̀lú sì láyọ̀ nínú ohun ìríra wọn;
Fún ìdí èyí ni èmi pẹ̀lú yóò ṣe fi ọwọ́ líle mú wọn
    n ó sì mú ohun tí wọ́n bẹ̀rù rẹ̀ wá sórí wọn.
Nítorí nígbà tí mo pè, kò sí ẹni tí ó dáhùn,
    nígbà tí mo sọ̀rọ̀, ẹnikẹ́ni kò tẹ́tí sílẹ̀.
Wọ́n ṣe ohun búburú ní ojú mi
    wọ́n sì yan ohun tí mo kórìíra rẹ̀.”

Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa,
    Ẹ̀yin tí ẹ ń wárìrì nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ rẹ̀:
“Àwọn arákùnrin yín tí wọ́n kórìíra yín,
    tí wọ́n ta yín nù nítorí orúkọ mi, wí pé,
    ‘Jẹ́ kí a yin Olúwa lógo,
kí a le rí ayọ̀ yín!’
    Ṣùgbọ́n àwọn ni ojú yóò tì.
(E)Gbọ́ rògbòdìyàn láti ìlú wá,
    gbọ́ ariwo náà láti tẹmpili wá!
Ariwo tí Olúwa ní í ṣe
    tí ó ń san án fún àwọn ọ̀tá rẹ̀ ohun
    tí ó tọ́ sí wọn.

(F)“Kí ó tó lọ sí ìrọbí,
    ó ti bímọ;
kí ó tó di pé ìrora dé bá a,
    ó ti bí ọmọkùnrin.
Ta ni ó ti gbọ́ irú nǹkan bẹ́ẹ̀ rí?
    Ta ni ó ti rí irú nǹkan bẹ́ẹ̀ rí?
Ǹjẹ́ a le bí orílẹ̀-èdè kan níjọ́ kan
    tàbí kí orílẹ̀-èdè lalẹ̀hù ní ìṣẹ́jú kan?
Síbẹ̀síbẹ̀ Sioni bẹ̀rẹ̀ rírọbí
    bẹ́ẹ̀ ni ó sì bí àwọn ọmọ rẹ̀.
Ǹjẹ́ èmi a ha máa mú wá sí ìrọbí
    kí èmi má sì mú ni bí?”
    ni Olúwa wí.
“Ǹjẹ́ èmi a ha máa ṣé ilé ọmọ
    nígbà tí mo ń mú ìbí wá?”
    Ni Ọlọ́run yín wí.
10 “Ẹ bá Jerusalẹmu yọ̀ kí inú yín kí ó sì dùn sí i,
    gbogbo ẹ̀yin tí ẹ fẹ́ràn rẹ̀;
ẹ yọ̀ gidigidi pẹ̀lú rẹ̀,
    gbogbo ẹ̀yin tí ó ti kẹ́dùn fún un.
11 Nítorí pé ẹ̀yin yóò mu ẹ o sì ní ìtẹ́lọ́rùn
    nínú ọmú rẹ̀ tí ó tu ni lára;
Ẹ̀yin yóò mu àmuyó
    ẹ ó sì gbádùn nínú àkúnwọ́sílẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ rẹ̀.”

12 Nítorí báyìí ni Olúwa wí:

“Èmi yóò fún un ní àlàáfíà gẹ́gẹ́ bí odò
    àti ọrọ̀ orílẹ̀-èdè gẹ́gẹ́ bí ìṣàn omi;
ẹ̀yin yóò mu ọmú, a ó sì gbé yín ní apá rẹ̀
    a ó bá yín ṣeré ní orúkún rẹ̀.
13 Gẹ́gẹ́ bí ìyá ti í tu ọmọ rẹ̀ nínú,
    bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò tù yín nínú
    a ó sì tù yín nínú lórí Jerusalẹmu.”

14 Nígbà tí ẹ bá rí èyí, inú yín yóò dùn
    ẹ̀yin yóò sì gbilẹ̀ gẹ́gẹ́ bí i koríko;
ọwọ́ Olúwa ni a ó sọ di mí mọ̀ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀,
    ṣùgbọ́n ìbínú rẹ̀ ni a ó fihàn fún àwọn ọ̀tá rẹ̀.
15 Kíyèsi i, Olúwa ń bọ̀ pẹ̀lú iná
    àti kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ tí ó dàbí ìjì líle;
òun yóò mú ìbínú rẹ sọ̀kalẹ̀ pẹ̀lú ìrunú,
    àti ìbáwí rẹ̀ pẹ̀lú ahọ́n iná.
16 Nítorí pẹ̀lú iná àti idà
    ni Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ lórí i gbogbo ènìyàn,
    àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí Olúwa yóò pa.

17 “Gbogbo àwọn tí wọ́n ya ara wọn sí mímọ́ tí wọ́n sì sọ ara wọn di mímọ́ láti lọ sínú ọgbà, tí wọ́n tẹ̀lé ẹni tí ó wà láàrín àwọn tí ó jẹ ẹran ẹlẹ́dẹ̀ àti èkúté àti àwọn ohun ìríra mìíràn ni wọn yóò bá òpin wọn pàdé papọ̀,” ni Olúwa wí.

18 “Àti Èmi, nítorí ìgbésẹ̀ wọn àti èrò wọn, èmi ti múra tán láti wá kó àwọn orílẹ̀-èdè àti ahọ́n jọ, wọn yóò sì wá wo ògo mi.

19 “Èmi yóò sì gbé ààmì kan kalẹ̀ láàrín wọn, èmi yóò sì rán díẹ̀ nínú àwọn tí ó sálà lọ sí àwọn orílẹ̀-èdè Tarṣiṣi, sí àwọn ará Libia àti Ludi, sí Tubali àti ará Giriki, àti sí àwọn erékùṣù tí ó jìnnà réré tí kò tí ìgbọ́ nípa òkìkí mi tàbí kí ó rí ògo mi. Wọn yóò kéde ògo mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè. 20 Wọn yóò sì mú àwọn arákùnrin yín wá, láti gbogbo orílẹ̀-èdè, sí òkè mímọ́ mi ní Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí ọrẹ sí Olúwa lórí ẹṣin, lórí kẹ̀kẹ́ ẹrù àti ọkọ-ẹṣin, àti lórí ìbáaka àti ìbákasẹ,” ni Olúwa wí. “Wọn yóò kó wọn wá, gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Israẹli ti mú ọrẹ oníhóró wọn wá, sínú Tẹmpili Olúwa nínú ohun èlò mímọ́. 21 Àti pé èmi yóò sì yan àwọn kan nínú wọn pẹ̀lú láti jẹ́ àlùfáà àti Lefi,” ni Olúwa wí.

22 (G)“Gẹ́gẹ́ bí àwọn ọ̀run tuntun àti ayé tuntun tí mo dá yóò ṣe wà níwájú mi títí láé,” ni Olúwa wí, “Bẹ́ẹ̀ ni orúkọ yín àti ìrandíran yín yóò pegedé. 23 Láti oṣù tuntun kan dé òmíràn àti láti ọjọ́ ìsinmi kan dé òmíràn, ni gbogbo ọmọ ènìyàn yóò wá, wọn yóò sì tẹríba níwájú mi,” ni Olúwa wí. 24 (H)“Wọn yóò sì jáde lọ wọn yóò sì lọ wo òkú àwọn tí wọ́n dìtẹ̀ sí mi; kòkòrò wọn kì yóò kú, bẹ́ẹ̀ ni iná wọn ni a kì yóò pa, bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò sì jẹ́ ohun ìríra fún gbogbo ọmọ ènìyàn.”

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)

Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.