Print Page Options
Previous Prev Day Next DayNext

Chronological

Read the Bible in the chronological order in which its stories and events occurred.
Duration: 365 days
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Version
Ẹkun Jeremiah 1:1-3:36

Báwo ni ìlú ṣe jókòó nìkan,
    nígbà kan tí ó sì kún fún ènìyàn!
Ó ti fìgbà kan jẹ́ ìlú olókìkí láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,
    tí ó wà ní ipò opó,
Ẹni tí ó jẹ́ ọmọ ọbabìnrin láàrín ìlú
    ni ó padà di ẹrú.

Ọ̀gànjọ́ òru ni ó fi máa ń sọkún kíkorò
    pẹ̀lú omijé ní ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀ tí ó dúró sí ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ̀.
Nínú gbogbo àwọn olólùfẹ́ rẹ̀
    kò sí ọ̀kan nínú wọn láti rẹ̀ ẹ́ lẹ́kún.
Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ ti jọ̀wọ́ rẹ̀
    wọ́n ti di alátakò rẹ̀.

Lẹ́yìn ìjìyà àti ìpọ́njú nínú oko ẹrú,
    Juda lọ sí àjò
Ó tẹ̀dó láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,
    ṣùgbọ́n kò rí ibi ìsinmi.
Àwọn tí ó ń tẹ̀lé ká á mọ́
    ibi tí kò ti le sá àsálà.

Gbogbo ọ̀nà tí ó wọ Sioni ń ṣọ̀fọ̀,
    nítorí ẹnìkan kò wá sí àjọ̀dún tí a yàn.
Gbogbo ẹnu-bodè rẹ̀ dahoro,
    àwọn àlùfáà rẹ̀ kẹ́dùn,
àwọn wúńdíá rẹ̀ sì ń káàánú,
    òun gan an wà ní ọkàn kíkorò.

Àwọn aninilára rẹ̀ gbogbo di olúwa rẹ̀,
    nǹkan sì rọrùn fún àwọn ọ̀tá rẹ̀,
Olúwa ti fún un ní ìjìyà tó tọ́
    nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.
Àwọn ẹ̀ṣọ́ wẹ́wẹ́ rẹ̀ lọ sí oko ẹrú,
    ìgbèkùn níwájú àwọn ọ̀tá.

Gbogbo ẹwà ti di ohun ìgbàgbé
    kúrò lọ́dọ̀ ọmọbìnrin Sioni.
    Àwọn ìjòyè rẹ̀ dàbí i àgbọ̀nrín
tí kò rí ewé tútù jẹ;
    nínú àárẹ̀ wọ́n sáré
níwájú ẹni tí ó ń lé wọn.

Ní ọjọ́ ìpọ́njú àti àrìnká rẹ̀ ni
    Jerusalẹmu rántí àwọn ohun ìní dáradára rẹ̀
    tí ó jẹ́ tirẹ̀ ní ọjọ́ pípẹ́.
Nígbà tí àwọn ènìyàn rẹ̀ ṣubú ṣọ́wọ́ àwọn ọ̀tá,
    kò sì ṣí olùrànlọ́wọ́ fún un.
Àwọn ọ̀tá rẹ̀ wò ó
    wọ́n sì ń fi ìparun rẹ̀ ṣẹlẹ́yà.

Jerusalẹmu sì ti dẹ́ṣẹ̀ púpọ̀
    ó sì ti di aláìmọ́.
Àwọn tí ó ń tẹríba fún un sì kẹ́gàn rẹ̀,
    nítorí wọ́n ti rí ìhòhò rẹ̀;
ó kérora fúnrarẹ̀,
    ó sì lọ kúrò.

Ìdọ̀tí wà ní etí aṣọ rẹ̀,
    bẹ́ẹ̀ ni kò wo ọjọ́ iwájú rẹ̀,
Ìṣubú rẹ̀ ya ni lẹ́nu;
    olùtùnú kò sì ṣí fún un.
“Wo ìpọ́njú mi, Olúwa,
    nítorí àwọn ọ̀tá ti borí.”

10 Ọ̀tá ti gbọ́wọ́ lé
    gbogbo ìní rẹ;
o rí pé àwọn orílẹ̀-èdè
    tí wọ́n wọ ibi mímọ́ rẹ—
àwọn tí o ti kọ̀sílẹ̀
    láti wọ ìpéjọpọ̀ rẹ.

11 Àwọn ènìyàn rẹ̀ ń kérora
    bí wọ́n ti ń wá oúnjẹ;
wọ́n fi ohun ìní wọn ṣe pàṣípàrọ̀ oúnjẹ
    láti mú wọn wà láààyè.
“Wò ó, Olúwa, kí o sì rò ó,
    nítorí a kọ̀ mí sílẹ̀.”

12 “Kò ha jẹ́ nǹkan kan sí i yín?
    Gbogbo ẹ̀yin tí ń rékọjá,
Ǹjẹ́ ẹnìkan ń jìyà bí èmi ti ń jìyà
    tí a fi fún mi, ti
Olúwa mú wá fún mi
    ní ọjọ́ ìbínú gbígbóná rẹ̀.

13 “Ó rán iná láti òkè
    sọ̀kalẹ̀ sínú egungun ara mi.
Ó dẹ àwọ̀n fún ẹsẹ̀ mi,
    ó sì yí mi padà.
Ó ti pa mí lára
    mó ń kú lọ ní gbogbo ọjọ́.

14 “Ẹ̀ṣẹ̀ mi ti di sísopọ̀ sí àjàgà;
    ọwọ́ rẹ̀ ni a fi hun ún papọ̀.
Wọ́n ti yí ọrùn mi ká
    Olúwa sì ti dín agbára mi kù.
Ó sì ti fi mí lé
    àwọn tí n kò le dojúkọ lọ́wọ́.

15 “Olúwa kọ
    àwọn akọni mi sílẹ̀,
ó rán àwọn ológun lòdì sí mi
    kí wọn pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin mi run.
Nínú ìfúntí wáìnì rẹ̀ Olúwa tẹ́
    àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin Juda.

16 “Ìdí nìyí tí mo fi ń sọkún
    tí omijé sì ń dà lójú mi,
Olùtùnú àti ẹni tí ó le mú ọkàn mi sọjí jìnnà sí mi,
    kò sí ẹni tí yóò dá ẹ̀mí mi padà.
Àwọn ọmọ mi di aláìní
    nítorí ọ̀tá ti borí.”

17 Sioni na ọwọ́ jáde,
    ṣùgbọ́n kò sí olùtùnú fún un.
Olúwa ti pàṣẹ fún Jakọbu
    pé àwọn ará ilé rẹ̀ di ọ̀tá fún un
Jerusalẹmu ti di
    ohun aláìmọ́ láàrín wọn.

18 “Olóòtítọ́ ni Olúwa,
    ṣùgbọ́n mo ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ rẹ̀.
Ẹ gbọ́, gbogbo ènìyàn;
    ẹ wò mí wò ìyà mi.
Gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin mi
    ni a ti kó lọ sí ìgbèkùn.

19 “Mo pe àwọn ọ̀rẹ́ mi
    ṣùgbọ́n wọ́n dà mí.
Àwọn olórí àlùfáà àti àgbàgbà mi
    ṣègbé sínú ìlú
nígbà tí wọ́n ń wá oúnjẹ
    tí yóò mú wọn wà láààyè.

20 Olúwa, wò ó, bí mo ti wà nínú ìnira!
    Tí mo sì ń jẹ̀rora nínú mi,
ìdààmú dé bá ọkàn mi
    nítorí pé a ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi gidigidi.
Ní gbangba ni idà ń parun;
    ikú wà nínú ilé pẹ̀lú.

21 “Àwọn ènìyàn ti gbọ́ ìrora mi,
    ṣùgbọ́n kò sí olùtùnú fún mi.
Àwọn ọ̀tá mi ti gbọ́ ìparun mi;
    wọ́n yọ̀ sí ohun tí o ṣe.
Kí o mú ọjọ́ tí o ti kéde,
    kí wọ́n le dàbí tèmi.

22 “Jẹ́ kí ìwà ìkà wọn wá síwájú rẹ;
    jẹ wọ́n ní yà
bí o ṣe jẹ mí ní yà
    nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi.
Ìrora mi pọ̀
    ọkàn mi sì rẹ̀wẹ̀sì.”

Báwo ni Olúwa ṣe bo ọmọbìnrin Sioni
    pẹ̀lú àwọsánmọ̀ ìbínú rẹ̀!
Ó sọ ògo Israẹli kalẹ̀
    Láti ọ̀run sí ayé;
kò rántí àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀
    ní ọjọ́ ìbínú rẹ̀.

Láìní àánú ni Olúwa gbé
    ibùgbé Jakọbu mì;
nínú ìrunú rẹ̀, ni ó wó
    ibi gíga ọmọbìnrin Juda lulẹ̀.
Ó ti mú ìjọba àti àwọn ọmọ-aládé ọkùnrin
    lọ sínú ilẹ̀ ní àìlọ́wọ̀.

Ní ìbínú gbígbóná rẹ̀ ni ó ké
    gbogbo ìwo Israẹli.
Ó ti mú ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ kúrò
    nígbà tí àwọn ọ̀tá dé.
Ó run ní Jakọbu bí ọ̀wọ́-iná
    ní àgọ́ àwọn ọmọbìnrin Sioni.

Ó na ọfà rẹ̀ bí ọ̀tá;
    ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ sì múra
Bí ti ọ̀tá tí ó ti parun
    ó tú ìbínú rẹ̀ jáde bí iná
sórí àgọ́ ọmọbìnrin Sioni.

Olúwa dàbí ọ̀tá;
    ó gbé Israẹli mì.
Ó ti gbé gbogbo ààfin rẹ̀ mì
    ó pa ibi gíga rẹ̀ run.
Ó sọ ìmí ẹ̀dùn àti ìbànújẹ́ di púpọ̀
    fún àwọn ọmọbìnrin Juda.

Ó mú ìparun bá ibi mímọ́,
    ó pa ibi ìpàdé rẹ̀ run.
Olúwa ti mú Sioni gbàgbé
    àjọ̀dún tí a yàn àti ọ̀sẹ̀ tí ó yàn;
nínú ìbínú gbígbóná rẹ̀ ni ó run
    ọba àti olórí àlùfáà.

Olúwa ti kọ̀ pẹpẹ rẹ̀ sílẹ̀
    ó sì ti kọ̀ ibi mímọ́ rẹ̀.
Ó sì fi lé ọ̀tá lọ́wọ́
    àwọn odi ààfin rẹ̀;
wọ́n sì kígbe ní ilé Olúwa
    gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ àpèjẹ tí a yàn.

Olúwa pinnu láti fa
    ògiri tí ó yí ọmọbìnrin Sioni ya.
Ó gbé wọn sórí òṣùwọ̀n,
    kò sì fa ọwọ́ rẹ̀ padà kúrò nínú ìparun wọn.
Ó mú kí ilé ìṣọ́ àti odi rẹ̀ ṣọ̀fọ̀
    wọ́n ṣòfò papọ̀.

Ẹnu-ọ̀nà rẹ̀ ti wọ inú ilẹ̀;
    òpó rẹ̀ ni ó wó tí ó sì ti bàjẹ́.
Ọba àti ọmọ ọbakùnrin rẹ̀ wà ní ìgbèkùn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,
    kò sí òfin mọ́,
àwọn wòlíì rẹ̀ kò rí
    ìran láti ọ̀dọ̀ Olúwa mọ́.

10 Àwọn àgbàgbà ọmọbìnrin Sioni
    jókòó sílẹ̀ ní ìdákẹ́rọ́rọ́;
wọ́n da eruku sí orí wọn
    wọ́n sì wọ aṣọ àkísà.
Àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin Jerusalẹmu
    ti tẹrí wọn ba sí ilẹ̀.

11 Ojú mi kọ̀ láti sọkún,
    mo ń jẹ ìrora nínú mi,
mo tú ọkàn mi jáde sí ilẹ̀
    nítorí a pa àwọn ènìyàn mí run,
nítorí àwọn ọmọdé àti ọmọ ọwọ́ ń kú
    ní òpópó ìlú.

12 Wọ́n wí fún àwọn ìyá wọn,
    “Níbo ni ọkà àti wáìnì wà?” Wò ó
bí wọ́n ṣe ń kú lọ bí àwọn ọkùnrin tí a ṣe léṣe
    ní àwọn òpópónà ìlú,
bí ayé wọn ṣe ń ṣòfò
    láti ọwọ́ ìyá wọn.

13 Kí ni mo le sọ fún ọ?
    Pẹ̀lú kí ni mo lè fi ọ́ wé,
    Ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu?
Kí sì ni mo lè fi ọ́ wé,
    kí n lè tù ọ́ nínú,
    Ìwọ wúńdíá obìnrin Sioni?
Ọgbẹ́ rẹ jì bí Òkun.
    Ta ni yóò wò ọ́ sàn?

14 Ìran àwọn wòlíì rẹ
    jẹ́ kìkì ẹ̀tàn láìní ìwọ̀n;
wọn kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ hàn
    tí yóò mú ìgbèkùn kúrò fún ọ.
Àwọn òrìṣà tí wọ́n fún ọ
    jẹ́ èké àti ìmúniṣìnà.

15 Àwọn tí ó gba ọ̀nà ọ̀dọ̀ rẹ
    pàtẹ́wọ́ lé ọ lórí;
wọ́n kẹ́gàn wọ́n ju orí wọn
    sí ọmọbìnrin Jerusalẹmu:
“Èyí ha ni ìlú tí à ń pè ní
    àṣepé ẹwà,
    ìdùnnú gbogbo ayé?”

16 Gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ la ẹnu wọn
    gbòòrò sí ọ;
wọ́n kẹ́gàn, wọ́n sì payínkeke
    wọ́n wí pé, “A ti gbé e mì tán.
Èyí ni ọjọ́ tí a ti ń retí;
    tí a sì wá láti rí.”

17 Olúwa ti ṣe ohun tí ó pinnu;
    ó ti mú ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣẹ,
    tí ó sì pàṣẹ ní ọjọ́ pípẹ́.
Ó ti ṣí ọ ní ipò láì láàánú,
    ó fún ọ̀tá ní ìṣẹ́gun lórí rẹ,
    ó ti gbé ìwo àwọn ọ̀tá rẹ̀ ga.

18 Ọkàn àwọn ènìyàn
    kígbe jáde sí Olúwa.
Odi ọmọbìnrin Sioni,
    jẹ́ kí ẹkún rẹ̀ sàn bí odò
    ní ọ̀sán àti òru;
má ṣe fi ara rẹ fún ìtura,
    ojú rẹ fún ìsinmi.

19 Dìde, kígbe sókè ní àṣálẹ́,
    bí ìṣọ́ òru ti bẹ̀rẹ̀
tú ọkàn rẹ̀ jáde bí omi
    níwájú Olúwa.
Gbé ọwọ́ yín sókè sí i
    nítorí ẹ̀mí àwọn èwe rẹ̀
tí ó ń kú lọ nítorí ebi
    ní gbogbo oríta òpópó.

20 “Wò ó, Olúwa, kí o sì rò ó:
    Ta ni ìwọ ti fìyà jẹ bí èyí
Ǹjẹ́ àwọn obìnrin yóò ha jẹ ọmọ wọn,
    àwọn ọmọ tí wọn ń ṣe ìtọ́jú fún?
Ǹjẹ́ kí a pa olórí àlùfáà àti àwọn wòlíì
    ní ibi mímọ́ Olúwa?

21 “Ọmọdé àti àgbà ń sùn papọ̀
    sínú eruku àwọn òpópó;
àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin mi
    ti ṣègbé nípa idà.
Ìwọ pa wọ́n run ní ọjọ́ ìbínú rẹ;
    Ìwọ pa wọ́n láìní àánú.

22 “Bí ó ti ṣe ní ọjọ́ àsè,
    bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe fi ẹ̀rù sí ẹ̀gbẹ́ mi.
Ní ọjọ́ ìbínú Olúwa
    kò sí ẹni tí ó sálà tí ó sì yè;
àwọn tí mo ti tọ́jú tí mo sì fẹ́ràn,
    ni ọ̀tá mi parun.”

Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú
    pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn
    nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀;
Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ padà sí mi
    síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.

Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó
    ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká
    pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn,
    bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.

Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ;
    ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́,
    ó kọ àdúrà mi.
Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi;
    ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.

10 Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀,
    bí i kìnnìún tí ó sápamọ́.
11 Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀
    ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
12 Ó fa ọfà rẹ̀ yọ
    ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.

13 Ó fa ọkàn mí ya
    pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
14 Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi;
    wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
15 Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò
    àti ìdààmú bí omi.

16 Ó ti fi òkúta kán eyín mi;
    ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
17 Mo ti jìnnà sí àlàáfíà;
    mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
18 Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ
    àti ìrètí mi nínú Olúwa.”

19 Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi,
    ìkorò àti ìbànújẹ́.
20 Mo ṣèrántí wọn,
    ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
21 Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn
    àti nítorí náà ní mo nírètí.

22 Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé,
    nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
23 Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀;
    títóbi ni òdodo rẹ̀.
24 Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa;
    nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.

25 Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀,
    sí àwọn tí ó ń wá a.
26 Ó dára kí a ní sùúrù
    fún ìgbàlà Olúwa.
27 Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà
    nígbà tí ó wà ní èwe.

28 Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́,
    nítorí Olúwa ti fi fún un.
29 Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku—
    ìrètí sì lè wà.
30 Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a,
    sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.

31 Ènìyàn kò di ìtanù
    lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
32 Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn,
    nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
33 Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá
    tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.

34 Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀
    gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
35 Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀
    níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ.
36 Láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà,
    Ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)

Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.