Print Page Options
Previous Prev Day Next DayNext

Revised Common Lectionary (Semicontinuous)

Daily Bible readings that follow the church liturgical year, with sequential stories told across multiple weeks.
Duration: 1245 days
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Version
Saamu 20

Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi.

20 Olúwa kí ó gbóhùn rẹ ní ọjọ́ ìpọ́njú;
    kí orúkọ Ọlọ́run Jakọbu kí ó dáàbò bò ọ́.
Kí ó rán ìrànlọ́wọ́ sí ọ, láti ibi mímọ́
    kí ó sì tì ọ́ lẹ́yìn láti Sioni wá.
Kí ó sì rántí gbogbo ẹbọ rẹ
    kí ó sì gba ẹbọ sísun rẹ. Sela
Kí ó fi fún ọ gẹ́gẹ́ bi ti èrò ọkàn rẹ
    kí ó sì mú gbogbo ìmọ̀ rẹ ṣẹ.
Àwa yóò hó fún ayọ̀ nígbà tí o bá di aṣẹ́gun
    àwa yóò gbé àsíá wa sókè ní orúkọ Ọlọ́run wa.

Kí Ọlọ́run kí ó mú gbogbo ìbéèrè rẹ̀ ṣẹ.

Nísinsin yìí, èmi mọ̀ wí pé:
    Olúwa pa ẹni ààmì òróró rẹ̀ mọ́.
Yóò gbọ́ láti ọ̀run mímọ́ rẹ̀ wá
    pẹ̀lú agbára ìgbàlà ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀.
Àwọn mìíràn gbẹ́kẹ̀ wọn lé kẹ̀kẹ́, àwọn mìíràn gbẹ́kẹ̀ wọn lé ẹṣin,
    ṣùgbọ́n àwa gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa Ọlọ́run wa.
Wọ́n wólẹ̀, ní eékún, wọ́n sì ṣubú,
    ṣùgbọ́n àwa dìde, a sì dúró ṣinṣin.
Olúwa, fi ìṣẹ́gun fún ọba!
    Dá wa lóhùn nígbà tí a bá ń kígbe pè!

Habakuku 3:2-15

Àdúrà Habakuku

Àdúrà wòlíì Habakuku gẹ́gẹ́ bí sígónótì. Ohun èlò orin.

Olúwa mo tí gbọ́ ohùn rẹ;
    ẹ̀rù sì ba mi fún iṣẹ́ rẹ Olúwa
sọ wọn di ọ̀tún ní ọjọ́ ti wa,
    ní àkókò tiwa, jẹ́ kó di mí mọ̀;
    ni ìbínú, rántí àánú.

Ọlọ́run yóò wa láti Temani,
    ibi mímọ́ jùlọ láti Òkè Parani
ògo rẹ̀ sí bo àwọn ọ̀run,
    ilé ayé sì kún fún ìyìn rẹ
Dídán rẹ sí dàbí ìmọ́lẹ̀ oòrùn
    ìtànṣán ìmọ́lẹ̀ jáde wa láti ọwọ́ rẹ,
    níbi tí wọn fi agbára rẹ̀ pamọ́ sí.
Àjàkálẹ̀-ààrùn ń lọ ni iwájú rẹ;
    ìyọnu sí ń tọ ẹsẹ̀ rẹ lọ.
Ó dúró, ó sì mi ayé;
    ó wò, ó sì mú àwọn orílẹ̀-èdè wárìrì
a sì tú àwọn òkè ńlá ayérayé ká,
    àwọn òkè kéékèèkéé ayérayé sì tẹríba:
    ọ̀nà rẹ ayérayé ni.
Mo rí àgọ́ Kuṣani nínú ìpọ́njú
    àti àwọn ibùgbé Midiani nínú ìrora.

Ǹjẹ́ ìwọ ha ń bínú sí àwọn Odò nì, Olúwa?
    Ǹjẹ́ ìbínú rẹ wa lórí àwọn odò ṣíṣàn bí?
Ìbínú rẹ ha wá sórí Òkun
    tí ìwọ fi ń gun ẹṣin,
    àti kẹ̀kẹ́ ìgbàlà rẹ?
A ṣí ọrun rẹ sílẹ̀ pátápátá,
    gẹ́gẹ́ bí ìbúra àwọn ẹ̀yà, àní ọ̀rọ̀ rẹ,
ìwọ sì fi odò pín ilẹ̀ ayé.
10     Àwọn òkè ńlá ri ọ wọn sì wárìrì
àgbàrá òjò ń sàn án kọjá lọ;
    ibú ń ké ramúramù
    ó sì gbé irú omi sókè.

11 Òòrùn àti Òṣùpá dúró jẹ́ẹ́jẹ́ ni ibùgbé wọn,
    pẹ̀lú ìmọ́lẹ̀ ọfà rẹ ni wọn yára lọ,
    àti ni dídán ọ̀kọ̀ rẹ ti ń kọ mànà.
12 Ní ìrunú ni ìwọ rin ilẹ̀ náà já,
    ní ìbínú ni ìwọ tí tẹ́ àwọn orílẹ̀-èdè rẹ.
13 Ìwọ jáde lọ láti tú àwọn ènìyàn rẹ sílẹ̀,
    àti láti gba ẹni ààmì òróró rẹ là;
Ìwọ ti run àwọn olórí kúrò nínú ilẹ̀ àwọn ènìyàn búburú,
    ó sì bọ ìhámọ́ra rẹ láti orí de ẹsẹ̀
14 Pẹ̀lú ọ̀kọ̀ rẹ̀ kí ó fi gún orí rẹ
    nígbà tí àwọn jagunjagun rẹ̀
jáde láti tú wá ká:
    ayọ̀ wọn sì ni láti jẹ tálákà run ní ìkọ̀kọ̀.
15 Ìwọ fi ẹṣin rẹ rìn Òkun já,
    ó sì da àwọn omi ńlá ru.

Luku 18:31-34

Jesu tún sọ nípa ikú rẹ̀

31 (A)Nígbà náà ni ó pe àwọn méjìlá sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì wí fún wọn pé, “Sá wò ó, àwa ń gòkè lọ sí Jerusalẹmu, a ó sì mú ohun gbogbo ṣẹ, tí a ti kọ láti ọwọ́ àwọn wòlíì, nítorí Ọmọ Ènìyàn. 32 Nítorí tí a ó fi lé àwọn aláìkọlà lọ́wọ́, a ó fi ṣe ẹlẹ́yà, a ó sì fi ṣe ẹ̀sín, a ó sì tutọ́ sí i lára. 33 Wọn ó sì nà án, wọn ó sì pa á: ní ọjọ́ kẹta yóò sì jíǹde.”

34 Ọ̀kan nínú nǹkan wọ̀nyí kò sì yé wọn: ọ̀rọ̀ yìí sì pamọ́ fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì mọ ohun tí a wí.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)

Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.