Isaiah 1-4
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
1 Ìran sí Juda àti Jerusalẹmu èyí tí Isaiah ọmọ Amosi rí ní àsìkò ìjọba Ussiah, Jotamu, Ahasi àti Hesekiah àwọn ọba Juda.
Ọlọ̀tẹ̀ orílẹ̀-èdè kan
2 Gbọ́ ẹ̀yin ọ̀run! Fi etí sílẹ̀, ìwọ ayé!
Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀:
“Mo tọ́ àwọn ọmọ dàgbà,
Ṣùgbọ́n wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi.
3 Màlúù mọ olówó rẹ̀,
kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì mọ ibùjẹ olówó rẹ̀,
ṣùgbọ́n Israẹli kò mọ̀,
òye kò yé àwọn ènìyàn mi.”
4 Á à! Orílẹ̀-èdè ẹlẹ́ṣẹ̀,
àwọn ènìyàn tí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ ń pa lẹ́rù,
Ìran àwọn aṣebi,
àwọn ọmọ tó ti di aṣèbàjẹ́!
Wọn ti kọ Olúwa sílẹ̀
wọn ti gan Ẹni Mímọ́ Israẹli,
wọn sì ti kẹ̀yìn sí i.
5 Èéṣe tí a ó fi tún lù yín mọ́?
Èéṣe tí ẹ ò dẹ́kun ọ̀tẹ̀ ṣíṣe?
Gbogbo orí yín jẹ́ kìkì ọgbẹ́,
gbogbo ọkàn yín sì ti pòruurù.
6 Láti àtẹ́lẹsẹ̀ yín dé àtàrí yín
kò sí àlàáfíà rárá,
àyàfi ọgbẹ́ òun ìfarapa
àti ojú egbò,
tí a kò nù kúrò tàbí kí á dì tàbí kí a kùn ún ní òróró.
7 Orílẹ̀-èdè yín dahoro,
a dáná sun àwọn ìlú yín,
oko yín ni àwọn àjèjì ti jẹ run
lójú ara yín náà,
ni gbogbo rẹ̀ ṣòfò bí èyí tí
àwọn àjèjì borí rẹ̀.
8 Ọmọbìnrin Sioni ni a fi sílẹ̀
gẹ́gẹ́ bí àtíbàbà nínú ọgbà àjàrà,
gẹ́gẹ́ bí abà nínú oko ẹ̀gúnsí,
àti bí ìlú tí a dó tì.
9 Àyàfi bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun
bá ṣẹ́ díẹ̀ kù fún wà,
a ò bá ti rí bí Sodomu,
a ò bá sì ti dàbí Gomorra.
10 Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa,
ẹ̀yin aláṣẹ Sodomu,
tẹ́tí sí òfin Ọlọ́run wa,
ẹ̀yin ènìyàn Gomorra!
11 “Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín
kín ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín jásí fún mi?” ni Olúwa wí.
“Mo ti ní ànító àti àníṣẹ́kù ẹbọ sísun
ti àgbò àti ọ̀rá ẹran àbọ́pa,
Èmi kò ní inú dídùn
nínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù, ti àgùntàn
àti ti òbúkọ.
12 Nígbà tí ẹ wá farahàn níwájú mi,
ta ni ó béèrè èyí lọ́wọ́ yín,
Gìrì gìrì ẹsẹ̀ nínú àgbàlá mi?
13 Ẹ má mú ọrẹ asán wá mọ́!
Ìríra ni tùràrí yín jásí fún mi,
oṣù tuntun àti ọjọ́ ìsinmi àti àwọn àpéjọ,
Èmi kò lè faradà á, ẹ̀ṣẹ̀ ni àpéjọ yín wọ̀nyí.
14 Ayẹyẹ oṣù tuntun yín àti àjọ̀dún tí a yàn,
ni ọkàn mi kórìíra.
Wọ́n ti di àjàgà sí mi ní ọrùn,
Ó sú mi láti fi ara dà wọ́n.
15 Nígbà tí ẹ bá tẹ́ ọwọ́ yín sókè ni àdúrà,
Èmi yóò fi ojú mi pamọ́ fún un yín,
kódà bí ẹ bá gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ àdúrà,
Èmi kò ni tẹ́tí sí i.
“Ọwọ́ yín kún fún ẹ̀jẹ̀.
16 “Wẹ̀ kí ẹ sì jẹ́ kí ara yín mọ́.
Ẹ mú ìwà ibi yín kúrò níwájú mi!
Dáwọ́ àìṣedéédéé dúró,
17 kọ́ láti ṣe rere!
Wá ìdájọ́ òtítọ́,
tu àwọn tí a ń pọ́n lójú nínú.
Ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba,
gbà ẹjọ́ opó rò.
18 “Ẹ wá ní ìsinsin yìí, ẹ jẹ́ kí a jọ ṣàṣàrò,”
ni Olúwa wí.
“Bí ẹ̀ṣẹ̀ yín bá rí bí osùn,
wọn ó sì funfun bí i yìnyín,
bí wọn bá sì pọ́n bí ẹ̀jẹ̀,
wọn ó sì dàbí ẹ̀gbọ̀n òwú.
19 Tí ẹ̀yin bá fẹ́, tí ẹ sì gbọ́rọ̀,
ẹ̀yin yóò sì jẹ ojúlówó adùn ilẹ̀ náà.
20 Ṣùgbọ́n tí ẹ bá kọ̀ tí ẹ sì ṣọ̀tẹ̀,
idà ni a ó fi pa yín run.”
Nítorí ẹnu Olúwa la ti sọ ọ́.
21 Wo bí ìlú òtítọ́ ṣe di àgbèrè!
Ó ti kún fún ìdájọ́ òtítọ́ nígbà kan rí,
òdodo ń gbé ibẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí,
ṣùgbọ́n báyìí àwọn apànìyàn!
22 Fàdákà rẹ ti di ìpẹ́pẹ́,
ààyò wáìnì rẹ la ti bu omi là.
23 Ọlọ̀tẹ̀ ni àwọn aláṣẹ yín,
akẹgbẹ́ àwọn olè,
gbogbo wọn ló fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀
wọ́n sì ń wá ẹ̀bùn kiri.
Wọ́n kì í ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba,
ẹjọ́ opó kì í sì í dé iwájú wọn.
24 Nítorí náà ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun,
alágbára kan ṣoṣo tí Israẹli sọ wí pé:
“Á à! Èmi yóò ní ìfọ̀kànbalẹ̀ lórí àwọn ọ̀tá mi
n ó sì gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá mi.
25 Èmi yóò pa ọwọ́ mi dà sí ọ,
èmi ó sì ku ìpẹ́pẹ́ rẹ dànù,
n ó sì mú gbogbo ìdọ̀tí rẹ kúrò.
26 Èmi yóò mú àwọn adájọ́ rẹ bọ̀ sí ipò gẹ́gẹ́ bí i ti àtijọ́,
àti àwọn olùdámọ̀ràn rẹ̀ bí i ti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀.
Lẹ́yìn náà ni a ó pè ọ ní ìlú òdodo, ìlú òtítọ́.”
27 A ó fi ìdájọ́ òtítọ́ ra Sioni padà,
àti àwọn tí ó ronúpìwàdà pẹ̀lú òdodo.
28 Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ̀tẹ̀ àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni a ó parun.
Àwọn tí ó bá sì kọ Olúwa sílẹ̀ ni yóò ṣègbé.
29 “Ojú yóò tì yín nítorí igi óákù mímọ́
èyí tí ẹ ní inú dídùn sí,
a ó kàn yín lábùkù nítorí àwọn ọgbà yìí
tí ẹ ti yàn fúnrayín.
30 Ẹ ó sì dàbí igi óákù tí ewé rẹ̀ ti rọ,
bí ọgbà tí kò ní omi.
31 Alágbára ọkùnrin náà yóò sì dàbí ohun ìdáná,
iṣẹ́ rẹ̀ bí ẹ̀ṣẹ́-iná,
àwọn méjèèjì ni yóò jóná papọ̀,
láìsí ẹni tí yóò lè pa iná yìí.”
Òkè Olúwa
2 Èyí ni ohun tí Isaiah ọmọ Amosi rí nípa Juda àti Jerusalẹmu:
2 (A)Ní ìgbẹ̀yìn ọjọ́
òkè tẹmpili Olúwa ni a ó fi ìdí rẹ̀ kalẹ̀
gẹ́gẹ́ bí olú nínú àwọn òkè,
a ó sì gbé e ga ju àwọn òkè kéékèèkéé lọ,
gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sì máa sàn sínú un rẹ̀.
3 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni yóò wá, wọn yóò sì wí pé,
“Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á gòkè ńlá Olúwa,
àti sí ilé Ọlọ́run Jakọbu.
Òun yóò kọ́ wa ní ọ̀nà rẹ̀,
kí àwa kí ó lè rìn ní ọ̀nà rẹ̀.”
Òfin yóò jáde láti Sioni wá,
àti ọ̀rọ̀ Olúwa láti Jerusalẹmu.
4 Òun ó ṣe ìdájọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,
yóò sì parí aáwọ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn.
Wọn yóò fi idà wọn rọ ọkọ́ ìtulẹ̀,
wọn yóò sì fi ọ̀kọ̀ wọn rọ dòjé.
Orílẹ̀-èdè kì yóò sì gbé idà sí orílẹ̀-èdè mọ́,
bẹ́ẹ̀ ní wọn kì yóò kọ́ ogun jíjà mọ́.
5 Wá, ẹ̀yìn ará ilé e Jakọbu,
ẹ jẹ́ kí a rìn nínú ìmọ́lẹ̀ Olúwa.
Ọjọ́ Olúwa
6 Ìwọ ti kọ àwọn ènìyàn rẹ sílẹ̀,
ìwọ ilé Jakọbu.
Wọ́n kún fún ìgbàgbọ́ tí kò lẹ́sẹ̀ nílẹ̀ tí ó ti ìlà-oòrùn wá,
wọ́n ń wo iṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí àwọn Filistini,
wọ́n ń pa ọwọ́ pọ̀ pẹ̀lú àwọn abọ̀rìṣà.
7 Ilẹ̀ wọn kún fún fàdákà àti wúrà,
ìṣúra wọn kò sì ní òpin.
Ilẹ̀ ẹ wọn kún fún ẹṣin,
kẹ̀kẹ́ ogun wọn kò sì lópin.
8 Ilẹ̀ ẹ wọn kún fún ère,
wọ́n sì ń foríbalẹ̀ fún iṣẹ́ ọwọ́ ara wọn,
èyí tí ìka ọwọ́ àwọn tìkára wọn ti ṣe.
9 Nítorí náà ni a ó ṣe rẹ ènìyàn sílẹ̀
ìran ọmọ ènìyàn ni yóò sì di onírẹ̀lẹ̀,
má ṣe dáríjì wọ́n.
10 Wọ inú àpáta lọ,
fi ara pamọ́ nínú erùpẹ̀
kúrò nínú ìpayà Olúwa,
àti ògo ọláńlá rẹ̀!
11 Ojú agbéraga ènìyàn ni a ó rẹ̀ sílẹ̀
a ó sì tẹrí ìgbéraga ènìyàn ba,
Olúwa nìkan ṣoṣo ni a ó gbéga ní ọjọ́ náà.
12 Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ọjọ́ kan ní ìpamọ́
fún gbogbo agbéraga àti ọlọ́kàn gíga
nítorí gbogbo àwọn tí a gbéga (ni a ó rẹ̀ sílẹ̀),
13 nítorí gbogbo igi kedari Lebanoni, tó ga tó rìpó
àti gbogbo óákù Baṣani,
14 nítorí gbogbo òkè gíga ńláńlá
àti àwọn òkè kéékèèkéé,
15 fún ilé ìṣọ́ gíga gíga
àti àwọn odi ìdáàbòbò,
16 fún gbogbo ọkọ̀ àwọn oníṣòwò
àwọn ọkọ̀ tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́.
17 Ìgbéraga ènìyàn ni a ó tẹ̀ lórí ba
a ó sì rẹ ìgbéraga ènìyàn sílẹ̀,
Olúwa nìkan ṣoṣo ni a ó gbéga ní ọjọ́ náà,
18 gbogbo ère òrìṣà yóò pòórá.
19 Àwọn ènìyàn yóò sálọ sínú ihò àpáta
àti sínú ihò ilẹ̀
kúrò lọ́wọ́ ìpayà Olúwa
àti ògo ọláńlá rẹ̀,
nígbà tí ó bá dìde láti mi ayé tìtì.
20 Ní ọjọ́ náà ni àwọn ènìyàn yóò máa sọ
àwọn ère fàdákà àti ère wúrà
tí wọ́n ti yá fún bíbọ
sí èkúté àti àwọn àdán,
21 Wọn yóò sálọ sínú ihò ìsàlẹ̀ àpáta
àti sínú ihò pàlàpálá àpáta
kúrò lọ́wọ́ ìpayà Olúwa
àti ògo ọláńlá rẹ̀,
nígbà tí ó bá dìde láti mi ayé tìtì.
22 Dẹ́kun à ń gba ènìyàn gbọ́,
èémí ẹni tó wà ní ihò imú rẹ̀.
Nítorí nínú kín ni a lè kà á sí?
Ìdájọ́ lórí i Jerusalẹmu àti Juda
3 Kíyèsi i, Olúwa,
Olúwa àwọn ọmọ-ogun,
fẹ́ mú ìpèsè àti ìrànlọ́wọ́ kúrò ní Jerusalẹmu àti Juda
gbogbo ìpèsè oúnjẹ àti ìpèsè omi.
2 Àwọn akíkanjú àti jagunjagun,
adájọ́ àti wòlíì,
aláfọ̀ṣẹ àti alàgbà,
3 balógun àádọ́ta àti àwọn ènìyàn, onípò gíga
olùdámọ̀ràn, oníṣọ̀nà tí ó dáńtọ́
àti ògbójú oníṣègùn.
4 “Èmi ó sọ àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin di aláṣẹ wọn,
ọ̀dọ́mọdé lásán làsàn ni yóò sì
máa jẹ ọba lórí i wọn.”
5 Àwọn ènìyàn yóò sì máa pọ́n
ọmọnìkejì wọn lójú
ẹnìkan sí ẹnìkejì rẹ̀, aládùúgbò
sí aládùúgbò rẹ̀.
Àwọn ọ̀dọ́ yóò gbógun ti àwọn àgbàgbà,
àwọn mẹ̀kúnnù yóò dìde sí ọlọ́lá.
6 Ọkùnrin kan yóò di ọ̀kan nínú àwọn
arákùnrin rẹ̀ mú,
nínú ilé baba rẹ̀, yóò sì wí pé,
“Ìwọ́ ní aṣọ, ìwọ máa ṣe olórí wa,
sì mójútó àwọn ahoro wọ̀nyí!”
7 Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ náà ni yóò figbe bọnu pé,
“Èmi kò ní àtúnṣe kan.
Èmi kò ní oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni n ó ní aṣọ nílé,
ẹ má fi mí ṣe olórí àwọn ènìyàn náà.”
8 Jerusalẹmu ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n
Juda ń ṣubú lọ,
ọ̀rọ̀ àti ìṣe wọn lòdì sí Olúwa,
láti mú ojú ògo rẹ̀ bínú.
9 Ìwò ojú wọn ń jẹ́rìí lòdì sí wọn,
wọ́n ń polongo ẹ̀ṣẹ̀ wọn bí i Sodomu;
wọn ò fi pamọ́!
Ègbé ni fún wọn!
Wọ́n ti mú ìparun wá sórí ara wọn.
10 Ẹ sọ fún olódodo pé yóò dára fún wọn,
nítorí ní àjẹgbádùn ni wọn yóò jẹ èso iṣẹ́ ẹ wọn.
11 Ègbé ni fún ènìyàn búburú! Ìparun wà lórí i wọn
A ó sì san èrè iṣẹ́ tí ọwọ́ wọn ti ṣe fún wọn.
12 Àwọn ọ̀dọ́mọdé ni o ń pọ́n àwọn ènìyàn mi lójú
àwọn obìnrin ń jẹ ọba lé wọn lórí.
Háà! Ènìyàn mi àwọn afinimọ̀nà yín ti ṣì yín lọ́nà,
wọn sì mú yín kúrò ní ipa ọ̀nà yín.
13 Olúwa bọ sí ipò rẹ̀ ní ìtẹ́ ìdájọ́
Ó dìde láti dá àwọn ènìyàn lẹ́jọ́.
14 Olúwa dojú ẹjọ́ kọ
àwọn àgbàgbà àti àwọn olórí àwọn ènìyàn rẹ̀.
“Ẹ̀yin ni ẹ ti run ọgbà àjàrà mi,
ogún àwọn tálákà ń bẹ̀ nínú ilé yín.
15 Kín ni èrò yín láti máa run àwọn ènìyàn mi túútúú
tí ẹ sì fojú àwọn tálákà ni gbolẹ̀?”
ni Olúwa wí, Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
16 Olúwa wí pé,
“Àwọn obìnrin Sioni jẹ́ agbéraga,
wọn ń rìn lọ pẹ̀lú ọrùn tí ó nà tàntàn,
tí wọn ń fojú pe ọkùnrin,
tí wọn ń sọ̀dí bí wọ́n ti ń yan lọ
pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́ tí ń mì wọnjanwọnjan lọ́rùn ẹsẹ̀ wọn.
17 Nítorí náà Olúwa yóò mú egbò wá sórí àwọn obìnrin Sioni,
Olúwa yóò sì pá wọn ní agbárí.”
18 Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò já ọ̀ṣọ́ wọn gbà kúrò ti ọwọ́ àti gèlè àti ẹ̀gbà ọrùn tí ó dàbí òṣùpá 19 gbogbo yẹtí, ẹ̀gbà ọwọ́ àti ìbòjú, 20 gbogbo gèlè, ẹ̀gbà ọrùn, ẹsẹ̀ àti àyà, àwọn ìgò tùràrí àti òògùn, 21 òrùka ọwọ́ àti ti imú, 22 àwọn àtàtà aṣọ, àwọ̀lékè, agbádá àti àpamọ́wọ́, 23 Dígí wọn, aṣọ funfun nigínnigín ìbòrí àti ìbòjú.
24 Dípò òórùn dídùn, òórùn búburú ni yóò wá,
okùn ni yóò wà dípò àmùrè,
orí pípá ni yóò dípò irun ti a ṣe ní ọ̀ṣọ́
aṣọ ọ̀fọ̀ ni yóò dípò aṣọ ẹ̀yẹ ìjóná dípò ẹwà.
25 Àwọn ọkùnrin rẹ yóò ti ipa idà ṣubú,
àti àwọn jagunjagun rẹ̀ lójú ogun.
26 Àwọn bodè Sioni yóò sọkún kíkorò, wọn ó ṣọ̀fọ̀,
nítorí ó dahoro, yóò jókòó ní orí ilẹ̀.
4 Ní ọjọ́ náà, obìnrin méje
yóò dì mọ́ ọkùnrin kan
yóò sì wí pé, “Àwa ó máa jẹ oúnjẹ ara wa
a ó sì pèsè aṣọ ara wa;
sá à jẹ́ kí a máa fi orúkọ rẹ̀ pè wá.
Mú ẹ̀gàn wa kúrò!”
Ẹ̀ka Olúwa náà
2 (B)Ní ọjọ́ náà, ẹ̀ka Olúwa yóò ní ẹwà àti ògo, èso ilẹ̀ náà yóò sì jẹ́ ìgbéraga àti ògo àwọn ti ó sálà ní Israẹli. 3 Àwọn tí ó ṣẹ́kù ní Sioni, àwọn tí o kù ní Jerusalẹmu, ni a ó pè ní mímọ́, orúkọ àwọn ẹni tí a kọ mọ́ àwọn alààyè ní Jerusalẹmu. 4 Olúwa yóò wẹ ẹ̀gbin àwọn obìnrin Sioni kúrò yóò sì fọ gbogbo àbàwọ́n ẹ̀jẹ̀ kúrò ní Jerusalẹmu pẹ̀lú ẹ̀mí ìdájọ́ àti ẹ̀mí iná. 5 Lẹ́yìn náà, Olúwa yóò dá sórí òkè Sioni àti sórí i gbogbo àwọn tí ó péjọpọ̀ síbẹ̀, kurukuru èéfín ní ọ̀sán àti ìtànṣán ọ̀wọ́-iná ní òru, lórí gbogbo ògo yìí ni ààbò yóò wà. 6 Èyí ni yóò jẹ́ ààbò àti òjìji kúrò lọ́wọ́ ooru ọ̀sán, àti ààbò òun ibi ìsádi kúrò lọ́wọ́ ìjì àti òjò.
Isaiah 1-4
New International Version
1 The vision(A) concerning Judah and Jerusalem(B) that Isaiah son of Amoz saw(C) during the reigns of Uzziah,(D) Jotham,(E) Ahaz(F) and Hezekiah,(G) kings of Judah.
A Rebellious Nation
2 Hear me, you heavens! Listen, earth!(H)
For the Lord has spoken:(I)
“I reared children(J) and brought them up,
but they have rebelled(K) against me.
3 The ox knows(L) its master,
the donkey its owner’s manger,(M)
but Israel does not know,(N)
my people do not understand.(O)”
4 Woe to the sinful nation,
a people whose guilt is great,(P)
a brood of evildoers,(Q)
children given to corruption!(R)
They have forsaken(S) the Lord;
they have spurned the Holy One(T) of Israel
and turned their backs(U) on him.
5 Why should you be beaten(V) anymore?
Why do you persist(W) in rebellion?(X)
Your whole head is injured,
your whole heart(Y) afflicted.(Z)
6 From the sole of your foot to the top of your head(AA)
there is no soundness(AB)—
only wounds and welts(AC)
and open sores,
not cleansed or bandaged(AD)
or soothed with olive oil.(AE)
7 Your country is desolate,(AF)
your cities burned with fire;(AG)
your fields are being stripped by foreigners(AH)
right before you,
laid waste as when overthrown by strangers.(AI)
8 Daughter Zion(AJ) is left(AK)
like a shelter in a vineyard,
like a hut(AL) in a cucumber field,
like a city under siege.
9 Unless the Lord Almighty
had left us some survivors,(AM)
we would have become like Sodom,
we would have been like Gomorrah.(AN)
10 Hear the word of the Lord,(AO)
you rulers of Sodom;(AP)
listen to the instruction(AQ) of our God,
you people of Gomorrah!(AR)
11 “The multitude of your sacrifices—
what are they to me?” says the Lord.
“I have more than enough of burnt offerings,
of rams and the fat of fattened animals;(AS)
I have no pleasure(AT)
in the blood of bulls(AU) and lambs and goats.(AV)
12 When you come to appear before me,
who has asked this of you,(AW)
this trampling of my courts?
13 Stop bringing meaningless offerings!(AX)
Your incense(AY) is detestable(AZ) to me.
New Moons,(BA) Sabbaths and convocations(BB)—
I cannot bear your worthless assemblies.
14 Your New Moon(BC) feasts and your appointed festivals(BD)
I hate with all my being.(BE)
They have become a burden to me;(BF)
I am weary(BG) of bearing them.
15 When you spread out your hands(BH) in prayer,
I hide(BI) my eyes from you;
even when you offer many prayers,
I am not listening.(BJ)
16 Wash(BM) and make yourselves clean.
Take your evil deeds out of my sight;(BN)
stop doing wrong.(BO)
17 Learn to do right;(BP) seek justice.(BQ)
Defend the oppressed.[a](BR)
Take up the cause of the fatherless;(BS)
plead the case of the widow.(BT)
18 “Come now, let us settle the matter,”(BU)
says the Lord.
“Though your sins are like scarlet,
they shall be as white as snow;(BV)
though they are red as crimson,
they shall be like wool.(BW)
19 If you are willing and obedient,(BX)
you will eat the good things of the land;(BY)
20 but if you resist and rebel,(BZ)
you will be devoured by the sword.”(CA)
For the mouth of the Lord has spoken.(CB)
21 See how the faithful city
has become a prostitute!(CC)
She once was full of justice;
righteousness(CD) used to dwell in her—
but now murderers!(CE)
22 Your silver has become dross,(CF)
your choice wine is diluted with water.
23 Your rulers are rebels,(CG)
partners with thieves;(CH)
they all love bribes(CI)
and chase after gifts.
They do not defend the cause of the fatherless;
the widow’s case does not come before them.(CJ)
24 Therefore the Lord, the Lord Almighty,
the Mighty One(CK) of Israel, declares:
“Ah! I will vent my wrath on my foes
and avenge(CL) myself on my enemies.(CM)
25 I will turn my hand against you;[b](CN)
I will thoroughly purge(CO) away your dross(CP)
and remove all your impurities.(CQ)
26 I will restore your leaders as in days of old,(CR)
your rulers as at the beginning.
Afterward you will be called(CS)
the City of Righteousness,(CT)
the Faithful City.(CU)”
27 Zion will be delivered with justice,
her penitent(CV) ones with righteousness.(CW)
28 But rebels and sinners(CX) will both be broken,
and those who forsake(CY) the Lord will perish.(CZ)
29 “You will be ashamed(DA) because of the sacred oaks(DB)
in which you have delighted;
you will be disgraced because of the gardens(DC)
that you have chosen.
30 You will be like an oak with fading leaves,(DD)
like a garden without water.
31 The mighty man will become tinder
and his work a spark;
both will burn together,
with no one to quench the fire.(DE)”
The Mountain of the Lord(DF)
2 This is what Isaiah son of Amoz saw concerning Judah and Jerusalem:(DG)
2 In the last days(DH)
the mountain(DI) of the Lord’s temple will be established
as the highest of the mountains;(DJ)
it will be exalted(DK) above the hills,
and all nations will stream to it.(DL)
3 Many peoples(DM) will come and say,
“Come, let us go(DN) up to the mountain(DO) of the Lord,
to the temple of the God of Jacob.
He will teach us his ways,
so that we may walk in his paths.”
The law(DP) will go out from Zion,
the word of the Lord from Jerusalem.(DQ)
4 He will judge(DR) between the nations
and will settle disputes(DS) for many peoples.
They will beat their swords into plowshares
and their spears into pruning hooks.(DT)
Nation will not take up sword against nation,(DU)
nor will they train for war anymore.
The Day of the Lord
6 You, Lord, have abandoned(DX) your people,
the descendants of Jacob.(DY)
They are full of superstitions from the East;
they practice divination(DZ) like the Philistines(EA)
and embrace(EB) pagan customs.(EC)
7 Their land is full of silver and gold;(ED)
there is no end to their treasures.(EE)
Their land is full of horses;(EF)
there is no end to their chariots.(EG)
8 Their land is full of idols;(EH)
they bow down(EI) to the work of their hands,(EJ)
to what their fingers(EK) have made.
9 So people will be brought low(EL)
and everyone humbled(EM)—
do not forgive them.[c](EN)
10 Go into the rocks, hide(EO) in the ground
from the fearful presence of the Lord
and the splendor of his majesty!(EP)
11 The eyes of the arrogant(EQ) will be humbled(ER)
and human pride(ES) brought low;(ET)
the Lord alone will be exalted(EU) in that day.(EV)
12 The Lord Almighty has a day(EW) in store
for all the proud(EX) and lofty,(EY)
for all that is exalted(EZ)
(and they will be humbled),(FA)
13 for all the cedars of Lebanon,(FB) tall and lofty,(FC)
and all the oaks of Bashan,(FD)
14 for all the towering mountains
and all the high hills,(FE)
15 for every lofty tower(FF)
and every fortified wall,(FG)
16 for every trading ship[d](FH)
and every stately vessel.
17 The arrogance of man will be brought low(FI)
and human pride humbled;(FJ)
the Lord alone will be exalted in that day,(FK)
18 and the idols(FL) will totally disappear.(FM)
19 People will flee to caves(FN) in the rocks
and to holes in the ground(FO)
from the fearful presence(FP) of the Lord
and the splendor of his majesty,(FQ)
when he rises to shake the earth.(FR)
20 In that day(FS) people will throw away
to the moles and bats(FT)
their idols of silver and idols of gold,(FU)
which they made to worship.(FV)
21 They will flee to caverns in the rocks(FW)
and to the overhanging crags
from the fearful presence of the Lord
and the splendor of his majesty,(FX)
when he rises(FY) to shake the earth.(FZ)
22 Stop trusting in mere humans,(GA)
who have but a breath(GB) in their nostrils.
Why hold them in esteem?(GC)
Judgment on Jerusalem and Judah
3 See now, the Lord,
the Lord Almighty,
is about to take from Jerusalem and Judah
both supply and support:(GD)
all supplies of food(GE) and all supplies of water,(GF)
2 the hero and the warrior,(GG)
the judge and the prophet,
the diviner(GH) and the elder,(GI)
3 the captain of fifty(GJ) and the man of rank,(GK)
the counselor, skilled craftsman(GL) and clever enchanter.(GM)
4 “I will make mere youths their officials;
children will rule over them.”(GN)
5 People will oppress each other—
man against man, neighbor against neighbor.(GO)
The young will rise up against the old,
the nobody against the honored.
6 A man will seize one of his brothers
in his father’s house, and say,
“You have a cloak, you be our leader;
take charge of this heap of ruins!”
7 But in that day(GP) he will cry out,
“I have no remedy.(GQ)
I have no food(GR) or clothing in my house;
do not make me the leader of the people.”(GS)
8 Jerusalem staggers,
Judah is falling;(GT)
their words(GU) and deeds(GV) are against the Lord,
defying(GW) his glorious presence.
9 The look on their faces testifies(GX) against them;
they parade their sin like Sodom;(GY)
they do not hide it.
Woe to them!
They have brought disaster(GZ) upon themselves.
10 Tell the righteous it will be well(HA) with them,
for they will enjoy the fruit of their deeds.(HB)
11 Woe to the wicked!(HC)
Disaster(HD) is upon them!
They will be paid back(HE)
for what their hands have done.(HF)
12 Youths(HG) oppress my people,
women rule over them.
My people, your guides lead you astray;(HH)
they turn you from the path.
13 The Lord takes his place in court;(HI)
he rises to judge(HJ) the people.
14 The Lord enters into judgment(HK)
against the elders and leaders of his people:
“It is you who have ruined my vineyard;
the plunder(HL) from the poor(HM) is in your houses.
15 What do you mean by crushing my people(HN)
and grinding(HO) the faces of the poor?”(HP)
declares the Lord, the Lord Almighty.(HQ)
16 The Lord says,
“The women of Zion(HR) are haughty,
walking along with outstretched necks,(HS)
flirting with their eyes,
strutting along with swaying hips,
with ornaments jingling on their ankles.
17 Therefore the Lord will bring sores on the heads of the women of Zion;
the Lord will make their scalps bald.(HT)”
18 In that day(HU) the Lord will snatch away their finery: the bangles and headbands and crescent necklaces,(HV) 19 the earrings and bracelets(HW) and veils,(HX) 20 the headdresses(HY) and anklets and sashes, the perfume bottles and charms, 21 the signet rings and nose rings,(HZ) 22 the fine robes and the capes and cloaks,(IA) the purses 23 and mirrors, and the linen garments(IB) and tiaras(IC) and shawls.
24 Instead of fragrance(ID) there will be a stench;(IE)
instead of a sash,(IF) a rope;
instead of well-dressed hair, baldness;(IG)
instead of fine clothing, sackcloth;(IH)
instead of beauty,(II) branding.(IJ)
25 Your men will fall by the sword,(IK)
your warriors in battle.(IL)
26 The gates(IM) of Zion will lament and mourn;(IN)
destitute,(IO) she will sit on the ground.(IP)
4 1 In that day(IQ) seven women
will take hold of one man(IR)
and say, “We will eat our own food(IS)
and provide our own clothes;
only let us be called by your name.
Take away our disgrace!”(IT)
The Branch of the Lord
2 In that day(IU) the Branch of the Lord(IV) will be beautiful(IW) and glorious, and the fruit(IX) of the land will be the pride and glory(IY) of the survivors(IZ) in Israel. 3 Those who are left in Zion,(JA) who remain(JB) in Jerusalem, will be called holy,(JC) all who are recorded(JD) among the living in Jerusalem. 4 The Lord will wash away the filth(JE) of the women of Zion;(JF) he will cleanse(JG) the bloodstains(JH) from Jerusalem by a spirit[e] of judgment(JI) and a spirit[f] of fire.(JJ) 5 Then the Lord will create(JK) over all of Mount Zion(JL) and over those who assemble there a cloud of smoke by day and a glow of flaming fire by night;(JM) over everything the glory[g](JN) will be a canopy.(JO) 6 It will be a shelter(JP) and shade from the heat of the day, and a refuge(JQ) and hiding place from the storm(JR) and rain.
Footnotes
- Isaiah 1:17 Or justice. / Correct the oppressor
- Isaiah 1:25 That is, against Jerusalem
- Isaiah 2:9 Or not raise them up
- Isaiah 2:16 Hebrew every ship of Tarshish
- Isaiah 4:4 Or the Spirit
- Isaiah 4:4 Or the Spirit
- Isaiah 4:5 Or over all the glory there
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
Holy Bible, New International Version®, NIV® Copyright ©1973, 1978, 1984, 2011 by Biblica, Inc.® Used by permission. All rights reserved worldwide.
NIV Reverse Interlinear Bible: English to Hebrew and English to Greek. Copyright © 2019 by Zondervan.
