Add parallel Print Page Options

Ìránṣẹ́ Olúwa Náà

49 (A)Tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin erékùṣù:
    gbọ́ èyí, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè jíjìnnà réré:
kí a tó bí mi Olúwa ti pè mí;
    láti ìgbà bíbí mi ni ó ti dá orúkọ mi.
Ó ṣe ẹnu mi bí idà tí a pọ́n,
    ní abẹ́ òjìji ọwọ́ rẹ̀ ni ó ti pa mí mọ́:
ó ṣe mí ní ọfà tí a ti dán,
    ó sì fi mí pamọ́ sínú àpò rẹ̀.
Ó sọ fún mi pé, “ìránṣẹ́ mi ni ìwọ í ṣe,
    Israẹli nínú ẹni tí n ó ti fi ògo mi hàn.”
(B)Ṣùgbọ́n èmi sọ pé, “Mo ti ṣe wàhálà lórí asán;
    mo ti lo gbogbo ipá mi lórí asán àti ìmúlẹ̀mófo.
Síbẹ̀síbẹ̀ ohun tí ó tọ́ sí mi ṣì wà lọ́wọ́ Olúwa,
    èrè mi sì ń bẹ pẹ̀lú Ọlọ́run mi.”

Nísinsin yìí Olúwa wí pé
    ẹni tí ó mọ̀ mí láti inú wá láti jẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀
láti mú Jakọbu padà tọ̀ mí wá
    àti láti kó Israẹli jọ sọ́dọ̀ ara rẹ̀,
nítorí pé a bọ̀wọ̀ fún mi ní ojú Olúwa
    Ọlọ́run mi sì ti jẹ́ agbára mi
(C)Òun wí pé:
    “Ó jẹ́ ohun kékeré fún ọ láti jẹ́ ìránṣẹ́ mi
láti mú ẹ̀yà Jakọbu padà bọ̀ sípò
    àti láti mú àwọn ti Israẹli tí mo ti pamọ́.
Èmi yóò sì fi ọ́ ṣe ìmọ́lẹ̀ fún àwọn kèfèrí,
    kí ìwọ kí ó lè mú ìgbàlà mi wá
    sí òpin ilẹ̀ ayé.”

Ohun tí Olúwa wí nìyìí—
    Olùdáǹdè àti Ẹni Mímọ́ Israẹli—
sí ẹni náà tí a gàn tí a sì kórìíra
    lọ́wọ́ àwọn orílẹ̀-èdè,
sí ìránṣẹ́ àwọn aláṣẹ:
    “Àwọn ọba yóò rí ọ wọn yóò sì dìde sókè,
àwọn ọmọ ọba yóò rí i wọn yóò sì wólẹ̀,
    nítorí Olúwa ẹni tí í ṣe olóòtítọ́,
    Ẹni Mímọ́ Israẹli tí ó ti yàn ọ́.”

Ìmúpadàbọ̀sípò Israẹli

(D)Ohun tí Olúwa wí nìyìí:

“Ní àkókò ojúrere mi, èmi yóò dá ọ lóhùn,
    àti ní ọjọ́ ìgbàlà, èmi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́;
Èmi yóò pa ọ́ mọ́, n ó sì ṣe ọ́
    láti jẹ́ májẹ̀mú fún àwọn ènìyàn,
láti mú ilẹ̀ padà bọ̀ sípò
    àti láti ṣe àtúnpín ogún rẹ̀ tí ó ti dahoro,
Láti sọ fún àwọn ìgbèkùn pé, ‘Ẹ jáde wá’
    àti fún àwọn tí ó wà nínú òkùnkùn pé, ‘Ẹ gba òmìnira!’

“Wọn yóò máa jẹ ní ẹ̀bá ọ̀nà
    àti koríko tútù lórí òkè aláìléwéko.
10 (E)Ebi kì yóò pa wọ́n bẹ́ẹ̀ ni òǹgbẹ kì yóò gbẹ wọ́n,
    tàbí kí ooru inú aṣálẹ̀ tàbí oòrùn kí ó pa wọ́n.
Ẹni tí ó ṣàánú fún wọn ni yóò máa tọ́ wọn,
    tí yóò sì mú wọn lọ sí ibi orísun omi.
11 Èmi yóò sọ gbogbo àwọn òkè-ńlá mi di ojú ọ̀nà
    àti gbogbo òpópónà mi ni a ó gbé sókè.
12 Kíyèsi i, wọn yóò wá láti ọ̀nà jíjìn
    àwọn díẹ̀ láti àríwá àti àwọn díẹ̀
láti ìwọ̀-oòrùn,
    àwọn díẹ̀ láti ẹkùn Siene.”

13 (F)Ẹ hó fún ayọ̀, ẹyin ọ̀run;
    yọ̀, ìwọ ilẹ̀ ayé;
bú sórin, ẹ̀yin òkè ńlá!
    Nítorí Olúwa tu àwọn ènìyàn rẹ̀ nínú
yóò sì ṣàánú fún àwọn ẹni
    tí a ń pọ́n lójú.

14 Ṣùgbọ́n Sioni sọ pé, “Olúwa ti kọ̀ mí sílẹ̀,
    Olúwa ti gbàgbé è mi.”

15 “Ǹjẹ́ abiyamọ ha le gbàgbé ọmọ ọmú rẹ̀
    kí ó má sì ṣàánú fún ọmọ rẹ̀ tí ó ti bí?
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun le gbàgbé
    Èmi kì yóò gbàgbé rẹ!
16 Kíyèsi i, mo ti kọ ọ́ sí àtẹ́lẹwọ́ mi
    ògiri rẹ wà níwájú mi nígbà gbogbo.
17 Àwọn ọmọ rẹ ti kánjú padà,
    àti àwọn tí ó sọ ọ́ dahoro ti padà lẹ́yìn rẹ.
18 Gbójú rẹ sókè kí o sì wò yíká;
    gbogbo àwọn ọmọkùnrin rẹ kórajọ
wọ́n sì wá sọ́dọ̀ rẹ.
    Níwọ́n ìgbà tí mo bá wà láààyè,” ni Olúwa wí,
“Ìwọ yóò wọ gbogbo wọ́n gẹ́gẹ́ bí ohun ọ̀ṣọ́;
    ìwọ yóò wọ̀ wọ́n gẹ́gẹ́ bí ìyàwó.

19 “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a tí run ọ́, a sì sọ ọ́ di ahoro
    tí gbogbo ilẹ̀ rẹ sì di ìparun,
ní ìsinsin yìí, ìwọ yóò kéré jù fún àwọn ènìyàn rẹ,
    bẹ́ẹ̀ ni àwọn tí ó jẹ ọ́ run ni yóò
    wà láti ọ̀nà jíjìn réré.
20 Àwọn ọmọ tí a bí ní àkókò ọ̀fọ̀ rẹ
    yóò sọ ní etígbọ̀ọ́ rẹ,
‘Ibi yìí ti kéré jù fún wa;
    ẹ fún wa láyè sí i tí a ó máa gbé.’
21 Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ ní ọkàn rẹ pé,
    ‘ta ló bí àwọn yìí fún mi?
Mo ti ṣọ̀fọ̀ mo sì yàgàn;
    A sọ mi di àtìpó a sì kọ̀ mí sílẹ̀.
Ta ló wo àwọn yìí dàgbà?
    A fi èmi nìkan sílẹ̀,
    ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí níbo ni wọ́n ti wá?’ ”

22 Ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nìyìí:

    “Kíyèsi i, Èmi yóò ké sí àwọn aláìkọlà
Èmi yóò gbé àsíá mi sókè sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn;
    Wọn yóò kó àwọn ọmọkùnrin yín wá ní apá wọn
wọn yóò sì gbé àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin
    ní èjìká wọn.
23 Àwọn ọba ni yóò jẹ́ alágbàtọ́ baba fún ọ,
    àwọn ayaba wọn ni yóò sì jẹ́ ìyá-alágbàtọ́.
Wọn yóò foríbalẹ̀ ní iwájú rẹ̀ pẹ̀lú ojú wọn dídàbolẹ̀;
    wọn yóò máa lá erùpẹ̀ lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ.
Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa;
    gbogbo àwọn tí wọ́n ní ìrètí nínú mi
    ni a kì yóò jákulẹ̀.”

24 Ǹjẹ́ a le gba ìkógun lọ́wọ́ jagunjagun,
    tàbí kí á gba ìgbèkùn lọ́wọ́ akíkanjú?

25 Ṣùgbọ́n ohun tí Olúwa wí nìyìí:

“Bẹ́ẹ̀ ni, a ó gba àwọn ìgbèkùn lọ́wọ́ àwọn jagunjagun,
    àti ìkógun lọ́wọ́ àwọn akíkanjú;
Ẹni tí ó bá ọ jà ni èmi ó bá jà,
    àti àwọn ọmọ rẹ ni èmi ó gbàlà.
26 Èmi yóò mú kí àwọn aninilára rẹ̀ jẹ
    ẹran-ara wọn;
wọn yóò mu ẹ̀jẹ̀ ara wọn yó
    bí ẹni mu wáìnì.
Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn yóò mọ̀
    pé Èmi, Olúwa, èmi ni Olùgbàlà rẹ,
    Olùdáǹdè rẹ, Alágbára kan ṣoṣo ti Jakọbu.”

49 Listen, O isles, unto me; and hearken, ye people, from far; The Lord hath called me from the womb; from the bowels of my mother hath he made mention of my name.

And he hath made my mouth like a sharp sword; in the shadow of his hand hath he hid me, and made me a polished shaft; in his quiver hath he hid me;

And said unto me, Thou art my servant, O Israel, in whom I will be glorified.

Then I said, I have laboured in vain, I have spent my strength for nought, and in vain: yet surely my judgment is with the Lord, and my work with my God.

And now, saith the Lord that formed me from the womb to be his servant, to bring Jacob again to him, Though Israel be not gathered, yet shall I be glorious in the eyes of the Lord, and my God shall be my strength.

And he said, It is a light thing that thou shouldest be my servant to raise up the tribes of Jacob, and to restore the preserved of Israel: I will also give thee for a light to the Gentiles, that thou mayest be my salvation unto the end of the earth.

Thus saith the Lord, the Redeemer of Israel, and his Holy One, to him whom man despiseth, to him whom the nation abhorreth, to a servant of rulers, Kings shall see and arise, princes also shall worship, because of the Lord that is faithful, and the Holy One of Israel, and he shall choose thee.

Thus saith the Lord, In an acceptable time have I heard thee, and in a day of salvation have I helped thee: and I will preserve thee, and give thee for a covenant of the people, to establish the earth, to cause to inherit the desolate heritages;

That thou mayest say to the prisoners, Go forth; to them that are in darkness, Shew yourselves. They shall feed in the ways, and their pastures shall be in all high places.

10 They shall not hunger nor thirst; neither shall the heat nor sun smite them: for he that hath mercy on them shall lead them, even by the springs of water shall he guide them.

11 And I will make all my mountains a way, and my highways shall be exalted.

12 Behold, these shall come from far: and, lo, these from the north and from the west; and these from the land of Sinim.

13 Sing, O heavens; and be joyful, O earth; and break forth into singing, O mountains: for the Lord hath comforted his people, and will have mercy upon his afflicted.

14 But Zion said, The Lord hath forsaken me, and my Lord hath forgotten me.

15 Can a woman forget her sucking child, that she should not have compassion on the son of her womb? yea, they may forget, yet will I not forget thee.

16 Behold, I have graven thee upon the palms of my hands; thy walls are continually before me.

17 Thy children shall make haste; thy destroyers and they that made thee waste shall go forth of thee.

18 Lift up thine eyes round about, and behold: all these gather themselves together, and come to thee. As I live, saith the Lord, thou shalt surely clothe thee with them all, as with an ornament, and bind them on thee, as a bride doeth.

19 For thy waste and thy desolate places, and the land of thy destruction, shall even now be too narrow by reason of the inhabitants, and they that swallowed thee up shall be far away.

20 The children which thou shalt have, after thou hast lost the other, shall say again in thine ears, The place is too strait for me: give place to me that I may dwell.

21 Then shalt thou say in thine heart, Who hath begotten me these, seeing I have lost my children, and am desolate, a captive, and removing to and fro? and who hath brought up these? Behold, I was left alone; these, where had they been?

22 Thus saith the Lord God, Behold, I will lift up mine hand to the Gentiles, and set up my standard to the people: and they shall bring thy sons in their arms, and thy daughters shall be carried upon their shoulders.

23 And kings shall be thy nursing fathers, and their queens thy nursing mothers: they shall bow down to thee with their face toward the earth, and lick up the dust of thy feet; and thou shalt know that I am the Lord: for they shall not be ashamed that wait for me.

24 Shall the prey be taken from the mighty, or the lawful captive delivered?

25 But thus saith the Lord, Even the captives of the mighty shall be taken away, and the prey of the terrible shall be delivered: for I will contend with him that contendeth with thee, and I will save thy children.

26 And I will feed them that oppress thee with their own flesh; and they shall be drunken with their own blood, as with sweet wine: and all flesh shall know that I the Lord am thy Saviour and thy Redeemer, the mighty One of Jacob.

A Light for the Nations

49 1-3 Listen, far-flung islands,
    pay attention, faraway people:
God put me to work from the day I was born.
    The moment I entered the world he named me.
He gave me speech that would cut and penetrate.
    He kept his hand on me to protect me.
He made me his straight arrow
    and hid me in his quiver.
He said to me, “You’re my dear servant,
    Israel, through whom I’ll shine.”

But I said, “I’ve worked for nothing.
    I’ve nothing to show for a life of hard work.
Nevertheless, I’ll let God have the last word.
    I’ll let him pronounce his verdict.”

5-6 “And now,” God says,
    this God who took me in hand
    from the moment of birth to be his servant,
To bring Jacob back home to him,
    to set a reunion for Israel—
What an honor for me in God’s eyes!
    That God should be my strength!
He says, “But that’s not a big enough job for my servant—
    just to recover the tribes of Jacob,
    merely to round up the strays of Israel.
I’m setting you up as a light for the nations
    so that my salvation becomes global!”

God, Redeemer of Israel, The Holy of Israel,
    says to the despised one, kicked around by the nations,
    slave labor to the ruling class:
“Kings will see, get to their feet—the princes, too—
    and then fall on their faces in homage
Because of God, who has faithfully kept his word,
    The Holy of Israel, who has chosen you.”

8-12 God also says:

“When the time’s ripe, I answer you.
    When victory’s due, I help you.
I form you and use you
    to reconnect the people with me,
To put the land in order,
    to resettle families on the ruined properties.
I tell prisoners, ‘Come on out. You’re free!’
    and those huddled in fear, ‘It’s all right. It’s safe now.’
There’ll be foodstands along all the roads,
    picnics on all the hills—
Nobody hungry, nobody thirsty,
    shade from the sun, shelter from the wind,
For the Compassionate One guides them,
    takes them to the best springs.
I’ll make all my mountains into roads,
    turn them into a superhighway.
Look: These coming from far countries,
    and those, out of the north,
These streaming in from the west,
    and those from all the way down the Nile!”

13 Heavens, raise the roof! Earth, wake the dead!
    Mountains, send up cheers!
God has comforted his people.
    He has tenderly nursed his beaten-up, beaten-down people.

14 But Zion said, “I don’t get it. God has left me.
    My Master has forgotten I even exist.”

15-18 “Can a mother forget the infant at her breast,
    walk away from the baby she bore?
But even if mothers forget,
    I’d never forget you—never.
Look, I’ve written your names on the backs of my hands.
    The walls you’re rebuilding are never out of my sight.
Your builders are faster than your wreckers.
    The demolition crews are gone for good.
Look up, look around, look well!
    See them all gathering, coming to you?
As sure as I am the living God”—God’s Decree—
    “you’re going to put them on like so much jewelry,
    you’re going to use them to dress up like a bride.

19-21 “And your ruined land?
    Your devastated, decimated land?
Filled with more people than you know what to do with!
    And your barbarian enemies, a fading memory.
The children born in your exile will be saying,
    ‘It’s getting too crowded here. I need more room.’
And you’ll say to yourself,
    ‘Where on earth did these children come from?
I lost everything, had nothing, was exiled and penniless.
    So who reared these children?
    How did these children get here?’”

22-23 The Master, God, says:

“Look! I signal to the nations,
    I raise my flag to summon the people.
Here they’ll come: women carrying your little boys in their arms,
    men carrying your little girls on their shoulders.
Kings will be your babysitters,
    princesses will be your nursemaids.
They’ll offer to do all your drudge work—
    scrub your floors, do your laundry.
You’ll know then that I am God.
    No one who hopes in me ever regrets it.”

24-26 Can plunder be retrieved from a giant,
    prisoners of war gotten back from a tyrant?
But God says, “Even if a giant grips the plunder
    and a tyrant holds my people prisoner,
I’m the one who’s on your side,
    defending your cause, rescuing your children.
And your enemies, crazed and desperate, will turn on themselves,
    killing each other in a frenzy of self-destruction.
Then everyone will know that I, God,
    have saved you—I, the Mighty One of Jacob.”