Add parallel Print Page Options

Ìránṣẹ́ Olúwa Náà

49 (A)Tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin erékùṣù:
    gbọ́ èyí, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè jíjìnnà réré:
kí a tó bí mi Olúwa ti pè mí;
    láti ìgbà bíbí mi ni ó ti dá orúkọ mi.
Ó ṣe ẹnu mi bí idà tí a pọ́n,
    ní abẹ́ òjìji ọwọ́ rẹ̀ ni ó ti pa mí mọ́:
ó ṣe mí ní ọfà tí a ti dán,
    ó sì fi mí pamọ́ sínú àpò rẹ̀.
Ó sọ fún mi pé, “ìránṣẹ́ mi ni ìwọ í ṣe,
    Israẹli nínú ẹni tí n ó ti fi ògo mi hàn.”
(B)Ṣùgbọ́n èmi sọ pé, “Mo ti ṣe wàhálà lórí asán;
    mo ti lo gbogbo ipá mi lórí asán àti ìmúlẹ̀mófo.
Síbẹ̀síbẹ̀ ohun tí ó tọ́ sí mi ṣì wà lọ́wọ́ Olúwa,
    èrè mi sì ń bẹ pẹ̀lú Ọlọ́run mi.”

Nísinsin yìí Olúwa wí pé
    ẹni tí ó mọ̀ mí láti inú wá láti jẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀
láti mú Jakọbu padà tọ̀ mí wá
    àti láti kó Israẹli jọ sọ́dọ̀ ara rẹ̀,
nítorí pé a bọ̀wọ̀ fún mi ní ojú Olúwa
    Ọlọ́run mi sì ti jẹ́ agbára mi
(C)Òun wí pé:
    “Ó jẹ́ ohun kékeré fún ọ láti jẹ́ ìránṣẹ́ mi
láti mú ẹ̀yà Jakọbu padà bọ̀ sípò
    àti láti mú àwọn ti Israẹli tí mo ti pamọ́.
Èmi yóò sì fi ọ́ ṣe ìmọ́lẹ̀ fún àwọn kèfèrí,
    kí ìwọ kí ó lè mú ìgbàlà mi wá
    sí òpin ilẹ̀ ayé.”

Ohun tí Olúwa wí nìyìí—
    Olùdáǹdè àti Ẹni Mímọ́ Israẹli—
sí ẹni náà tí a gàn tí a sì kórìíra
    lọ́wọ́ àwọn orílẹ̀-èdè,
sí ìránṣẹ́ àwọn aláṣẹ:
    “Àwọn ọba yóò rí ọ wọn yóò sì dìde sókè,
àwọn ọmọ ọba yóò rí i wọn yóò sì wólẹ̀,
    nítorí Olúwa ẹni tí í ṣe olóòtítọ́,
    Ẹni Mímọ́ Israẹli tí ó ti yàn ọ́.”

Ìmúpadàbọ̀sípò Israẹli

(D)Ohun tí Olúwa wí nìyìí:

“Ní àkókò ojúrere mi, èmi yóò dá ọ lóhùn,
    àti ní ọjọ́ ìgbàlà, èmi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́;
Èmi yóò pa ọ́ mọ́, n ó sì ṣe ọ́
    láti jẹ́ májẹ̀mú fún àwọn ènìyàn,
láti mú ilẹ̀ padà bọ̀ sípò
    àti láti ṣe àtúnpín ogún rẹ̀ tí ó ti dahoro,
Láti sọ fún àwọn ìgbèkùn pé, ‘Ẹ jáde wá’
    àti fún àwọn tí ó wà nínú òkùnkùn pé, ‘Ẹ gba òmìnira!’

“Wọn yóò máa jẹ ní ẹ̀bá ọ̀nà
    àti koríko tútù lórí òkè aláìléwéko.
10 (E)Ebi kì yóò pa wọ́n bẹ́ẹ̀ ni òǹgbẹ kì yóò gbẹ wọ́n,
    tàbí kí ooru inú aṣálẹ̀ tàbí oòrùn kí ó pa wọ́n.
Ẹni tí ó ṣàánú fún wọn ni yóò máa tọ́ wọn,
    tí yóò sì mú wọn lọ sí ibi orísun omi.
11 Èmi yóò sọ gbogbo àwọn òkè-ńlá mi di ojú ọ̀nà
    àti gbogbo òpópónà mi ni a ó gbé sókè.
12 Kíyèsi i, wọn yóò wá láti ọ̀nà jíjìn
    àwọn díẹ̀ láti àríwá àti àwọn díẹ̀
láti ìwọ̀-oòrùn,
    àwọn díẹ̀ láti ẹkùn Siene.”

13 (F)Ẹ hó fún ayọ̀, ẹyin ọ̀run;
    yọ̀, ìwọ ilẹ̀ ayé;
bú sórin, ẹ̀yin òkè ńlá!
    Nítorí Olúwa tu àwọn ènìyàn rẹ̀ nínú
yóò sì ṣàánú fún àwọn ẹni
    tí a ń pọ́n lójú.

14 Ṣùgbọ́n Sioni sọ pé, “Olúwa ti kọ̀ mí sílẹ̀,
    Olúwa ti gbàgbé è mi.”

15 “Ǹjẹ́ abiyamọ ha le gbàgbé ọmọ ọmú rẹ̀
    kí ó má sì ṣàánú fún ọmọ rẹ̀ tí ó ti bí?
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun le gbàgbé
    Èmi kì yóò gbàgbé rẹ!
16 Kíyèsi i, mo ti kọ ọ́ sí àtẹ́lẹwọ́ mi
    ògiri rẹ wà níwájú mi nígbà gbogbo.
17 Àwọn ọmọ rẹ ti kánjú padà,
    àti àwọn tí ó sọ ọ́ dahoro ti padà lẹ́yìn rẹ.
18 Gbójú rẹ sókè kí o sì wò yíká;
    gbogbo àwọn ọmọkùnrin rẹ kórajọ
wọ́n sì wá sọ́dọ̀ rẹ.
    Níwọ́n ìgbà tí mo bá wà láààyè,” ni Olúwa wí,
“Ìwọ yóò wọ gbogbo wọ́n gẹ́gẹ́ bí ohun ọ̀ṣọ́;
    ìwọ yóò wọ̀ wọ́n gẹ́gẹ́ bí ìyàwó.

19 “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a tí run ọ́, a sì sọ ọ́ di ahoro
    tí gbogbo ilẹ̀ rẹ sì di ìparun,
ní ìsinsin yìí, ìwọ yóò kéré jù fún àwọn ènìyàn rẹ,
    bẹ́ẹ̀ ni àwọn tí ó jẹ ọ́ run ni yóò
    wà láti ọ̀nà jíjìn réré.
20 Àwọn ọmọ tí a bí ní àkókò ọ̀fọ̀ rẹ
    yóò sọ ní etígbọ̀ọ́ rẹ,
‘Ibi yìí ti kéré jù fún wa;
    ẹ fún wa láyè sí i tí a ó máa gbé.’
21 Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ ní ọkàn rẹ pé,
    ‘ta ló bí àwọn yìí fún mi?
Mo ti ṣọ̀fọ̀ mo sì yàgàn;
    A sọ mi di àtìpó a sì kọ̀ mí sílẹ̀.
Ta ló wo àwọn yìí dàgbà?
    A fi èmi nìkan sílẹ̀,
    ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí níbo ni wọ́n ti wá?’ ”

22 Ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nìyìí:

    “Kíyèsi i, Èmi yóò ké sí àwọn aláìkọlà
Èmi yóò gbé àsíá mi sókè sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn;
    Wọn yóò kó àwọn ọmọkùnrin yín wá ní apá wọn
wọn yóò sì gbé àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin
    ní èjìká wọn.
23 Àwọn ọba ni yóò jẹ́ alágbàtọ́ baba fún ọ,
    àwọn ayaba wọn ni yóò sì jẹ́ ìyá-alágbàtọ́.
Wọn yóò foríbalẹ̀ ní iwájú rẹ̀ pẹ̀lú ojú wọn dídàbolẹ̀;
    wọn yóò máa lá erùpẹ̀ lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ.
Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa;
    gbogbo àwọn tí wọ́n ní ìrètí nínú mi
    ni a kì yóò jákulẹ̀.”

24 Ǹjẹ́ a le gba ìkógun lọ́wọ́ jagunjagun,
    tàbí kí á gba ìgbèkùn lọ́wọ́ akíkanjú?

25 Ṣùgbọ́n ohun tí Olúwa wí nìyìí:

“Bẹ́ẹ̀ ni, a ó gba àwọn ìgbèkùn lọ́wọ́ àwọn jagunjagun,
    àti ìkógun lọ́wọ́ àwọn akíkanjú;
Ẹni tí ó bá ọ jà ni èmi ó bá jà,
    àti àwọn ọmọ rẹ ni èmi ó gbàlà.
26 Èmi yóò mú kí àwọn aninilára rẹ̀ jẹ
    ẹran-ara wọn;
wọn yóò mu ẹ̀jẹ̀ ara wọn yó
    bí ẹni mu wáìnì.
Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn yóò mọ̀
    pé Èmi, Olúwa, èmi ni Olùgbàlà rẹ,
    Olùdáǹdè rẹ, Alágbára kan ṣoṣo ti Jakọbu.”

The Servant of the Lord

49 Listen(A) to me, you islands;(B)
    hear this, you distant nations:
Before I was born(C) the Lord called(D) me;
    from my mother’s womb he has spoken my name.(E)
He made my mouth(F) like a sharpened sword,(G)
    in the shadow of his hand(H) he hid me;
he made me into a polished arrow(I)
    and concealed me in his quiver.
He said to me, “You are my servant,(J)
    Israel, in whom I will display my splendor.(K)
But I said, “I have labored in vain;(L)
    I have spent my strength for nothing at all.
Yet what is due me is in the Lord’s hand,(M)
    and my reward(N) is with my God.”(O)

And now the Lord says—
    he who formed me in the womb(P) to be his servant
to bring Jacob back to him
    and gather Israel(Q) to himself,
for I am[a] honored(R) in the eyes of the Lord
    and my God has been my strength(S)
he says:
“It is too small a thing for you to be my servant(T)
    to restore the tribes of Jacob
    and bring back those of Israel I have kept.(U)
I will also make you a light(V) for the Gentiles,(W)
    that my salvation may reach to the ends of the earth.”(X)

This is what the Lord says—
    the Redeemer and Holy One of Israel(Y)
to him who was despised(Z) and abhorred by the nation,
    to the servant of rulers:
“Kings(AA) will see you and stand up,
    princes will see and bow down,(AB)
because of the Lord, who is faithful,(AC)
    the Holy One of Israel, who has chosen(AD) you.”

Restoration of Israel

This is what the Lord says:

“In the time of my favor(AE) I will answer you,
    and in the day of salvation I will help you;(AF)
I will keep(AG) you and will make you
    to be a covenant for the people,(AH)
to restore the land(AI)
    and to reassign its desolate inheritances,(AJ)
to say to the captives,(AK) ‘Come out,’
    and to those in darkness,(AL) ‘Be free!’

“They will feed beside the roads
    and find pasture on every barren hill.(AM)
10 They will neither hunger nor thirst,(AN)
    nor will the desert heat or the sun beat down on them.(AO)
He who has compassion(AP) on them will guide(AQ) them
    and lead them beside springs(AR) of water.
11 I will turn all my mountains into roads,
    and my highways(AS) will be raised up.(AT)
12 See, they will come from afar(AU)
    some from the north, some from the west,(AV)
    some from the region of Aswan.[b]

13 Shout for joy,(AW) you heavens;
    rejoice, you earth;(AX)
    burst into song, you mountains!(AY)
For the Lord comforts(AZ) his people
    and will have compassion(BA) on his afflicted ones.(BB)

14 But Zion(BC) said, “The Lord has forsaken(BD) me,
    the Lord has forgotten me.”

15 “Can a mother forget the baby at her breast
    and have no compassion on the child(BE) she has borne?
Though she may forget,
    I will not forget you!(BF)
16 See, I have engraved(BG) you on the palms of my hands;
    your walls(BH) are ever before me.
17 Your children hasten back,
    and those who laid you waste(BI) depart from you.
18 Lift up your eyes and look around;
    all your children gather(BJ) and come to you.
As surely as I live,(BK)” declares the Lord,
    “you will wear(BL) them all as ornaments;
    you will put them on, like a bride.

19 “Though you were ruined and made desolate(BM)
    and your land laid waste,(BN)
now you will be too small for your people,(BO)
    and those who devoured(BP) you will be far away.
20 The children born during your bereavement
    will yet say in your hearing,
‘This place is too small for us;
    give us more space to live in.’(BQ)
21 Then you will say in your heart,
    ‘Who bore me these?(BR)
I was bereaved(BS) and barren;
    I was exiled and rejected.(BT)
    Who brought these(BU) up?
I was left(BV) all alone,(BW)
    but these—where have they come from?’”

22 This is what the Sovereign Lord(BX) says:

“See, I will beckon to the nations,
    I will lift up my banner(BY) to the peoples;
they will bring(BZ) your sons in their arms
    and carry your daughters on their hips.(CA)
23 Kings(CB) will be your foster fathers,
    and their queens your nursing mothers.(CC)
They will bow down(CD) before you with their faces to the ground;
    they will lick the dust(CE) at your feet.
Then you will know that I am the Lord;(CF)
    those who hope(CG) in me will not be disappointed.(CH)

24 Can plunder be taken from warriors,(CI)
    or captives be rescued from the fierce[c]?

25 But this is what the Lord says:

“Yes, captives(CJ) will be taken from warriors,(CK)
    and plunder retrieved from the fierce;(CL)
I will contend with those who contend with you,(CM)
    and your children I will save.(CN)
26 I will make your oppressors(CO) eat(CP) their own flesh;
    they will be drunk on their own blood,(CQ) as with wine.
Then all mankind will know(CR)
    that I, the Lord, am your Savior,(CS)
    your Redeemer,(CT) the Mighty One of Jacob.(CU)

Footnotes

  1. Isaiah 49:5 Or him, / but Israel would not be gathered; / yet I will be
  2. Isaiah 49:12 Dead Sea Scrolls; Masoretic Text Sinim
  3. Isaiah 49:24 Dead Sea Scrolls, Vulgate and Syriac (see also Septuagint and verse 25); Masoretic Text righteous