Revised Common Lectionary (Semicontinuous)
Saamu ti Dafidi.
29 Ẹ fi fún Olúwa, ẹ̀yin ẹ̀dá ọ̀run,
Ẹ fi fún Olúwa, ògo àti alágbára.
2 Fi fún Olúwa, àní ògo orúkọ rẹ̀;
sin Olúwa nínú ẹwà ìwà mímọ́.
3 Ohùn Olúwa n ré àwọn omi kọjá;
Ọlọ́run ògo sán àrá,
Olúwa san ara.
4 Ohùn Olúwa ní agbára;
ohùn Olúwa kún fún ọláńlá.
5 Ohùn Olúwa fa igi kedari;
Olúwa náà ló fọ́ igi kedari Lebanoni ya.
6 Ó mú Lebanoni fo bí i ọmọ màlúù,
àti Sirioni bí ọmọ àgbáǹréré.
7 Ohùn Olúwa ń ya
bí ọwọ́ iná mọ̀nà
8 Ohùn Olúwa ń mi aginjù.
Olúwa mi aginjù Kadeṣi.
9 Ohùn Olúwa ní ó lọ igi óákù, ó n mú abo àgbọ̀nrín bí,
ó sì bọ́ igi igbó sí ìhòhò.
Àti nínú tẹmpili rẹ̀ gbogbo ohùn wí pé “Ògo!”
10 Olúwa jókòó, Ó sì jẹ ọba lórí ìṣàn omi;
Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ gẹ́gẹ́ bí Ọba títí láéláé.
11 Kí Olúwa fi agbára fún àwọn ènìyàn rẹ̀;
bùkún àwọn ènìyàn rẹ̀ pẹ̀lú àlàáfíà.
39 “Ìwọ ha dẹ ọdẹ fún abo kìnnìún bí?
Ìwọ ó sì tẹ ebi ẹgbọrọ kìnnìún lọ́rùn,
40 Nígbà tí wọ́n bá mọ́lẹ̀ nínú ihò
tí wọ́n sì ba ní ibùba de ohun ọdẹ?
41 Ta ni ó ń pèsè ohun jíjẹ fún ẹyẹ ìwò,
nígbà tí àwọn ọmọ rẹ ń ké pe Ọlọ́run,
tí wọ́n sì máa ń fò kiri nítorí àìní ohun jíjẹ?
Agbára Ọlọ́run
39 “Ìwọ mọ àkókò ìgbà tí àwọn ewúrẹ́ orí àpáta ń bímọ?
Ìwọ sì lè kíyèsi ìgbà tí abo àgbọ̀nrín ń bímọ?
2 Ìwọ lè ka iye òṣùpá tí wọn ń pé,
ìwọ sì mọ àkókò ìgbà tí wọn ń bímọ,
3 Wọ́n tẹ ara wọn ba, wọ́n bímọ,
wọ́n sì mú ìkáàánú wọn jáde.
4 Àwọn ọmọ wọn rí dáradára, wọ́n dàgbà nínú ọ̀dàn;
wọ́n jáde lọ, wọn kò sì tún padà wá sọ́dọ̀ wọn.
5 “Ta ni ó jọ̀wọ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ oko lọ́wọ́?
Tàbí ta ní ó tú ìdè kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó,
6 Èyí tí mo fi aginjù ṣe ilé fún,
àti ilẹ̀ iyọ̀ ní ibùgbé rẹ̀.
7 Ó rẹ́rìn-ín sí ariwo ìlú,
bẹ́ẹ̀ ni òun kò sì gbọ́ igbe darandaran.
8 Orí àtòlé òkè ńlá ni ibùjẹ oko rẹ̀,
Òun a sì máa wá ewé tútù gbogbo rí.
9 “Àgbáǹréré ha jẹ́ sìn ọ́ bí?
Tàbí ó jẹ́ dúró ní ibùjẹ ẹran rẹ ní òru?
10 Ìwọ le fi Òkun tata de àgbáǹréré nínú aporo?
Tàbí ó jẹ́ máa fa ìtulẹ̀ nínú aporo oko tọ̀ ọ́ lẹ́yìn?
11 Ìwọ ó gbẹ́kẹ̀lé e nítorí agbára rẹ̀ pọ̀?
Ìwọ ó sì fi iṣẹ́ rẹ lé e lọ́wọ́?
12 Ìwọ le gbẹ́kẹ̀lé pé, yóò mú èso oko rẹ̀ wá sílé,
àti pé yóò sì kó ọ jọ sínú àká rẹ?
Ẹ̀bùn Ẹ̀mí Mímọ́
12 Ní ti Ẹ̀mí Mímọ́ ẹ̀yin ará, kò yẹ́ kí ẹ jẹ́ òpè. 2 (A)Ẹ̀yin kò mọ̀ pé nígbà tí ẹ̀yin jẹ́ kèfèrí, a fà yín lọ sọ́dọ̀ àwọn odi òrìṣà. 3 (B)Nítorí náà, èmí ń sọ fún un yín pé kò sí ẹni ti ń sọ̀rọ̀ nípasẹ̀ Ẹ̀mí Ọlọ́run tí ó lè wí pé, “Ẹni ìfibú ni Jesu,” àti pé kò sí ẹni tí ó lè sọ pé, “Olúwa ni Jesu,” bí kò ṣe nípasẹ̀ Ẹ̀mí mímọ́.
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.