Old/New Testament
3 Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú
pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
2 Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn
nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀;
3 Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ padà sí mi
síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
4 Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó
ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
5 Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká
pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
6 Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn,
bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
7 Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ;
ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
8 Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́,
ó kọ àdúrà mi.
9 Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi;
ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
10 Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀,
bí i kìnnìún tí ó sápamọ́.
11 Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀
ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
12 Ó fa ọfà rẹ̀ yọ
ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
13 Ó fa ọkàn mí ya
pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
14 Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi;
wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
15 Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò
àti ìdààmú bí omi.
16 Ó ti fi òkúta kán eyín mi;
ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
17 Mo ti jìnnà sí àlàáfíà;
mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
18 Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ
àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
19 Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi,
ìkorò àti ìbànújẹ́.
20 Mo ṣèrántí wọn,
ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
21 Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn
àti nítorí náà ní mo nírètí.
22 Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé,
nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
23 Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀;
títóbi ni òdodo rẹ̀.
24 Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa;
nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
25 Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀,
sí àwọn tí ó ń wá a.
26 Ó dára kí a ní sùúrù
fún ìgbàlà Olúwa.
27 Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà
nígbà tí ó wà ní èwe.
28 Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́,
nítorí Olúwa ti fi fún un.
29 Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku—
ìrètí sì lè wà.
30 Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a,
sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
31 Ènìyàn kò di ìtanù
lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
32 Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn,
nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
33 Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá
tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
34 Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀
gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
35 Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀
níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ.
36 Láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà,
Ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
37 Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀
tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
38 Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ
ni rere àti búburú tí ń wá?
39 Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn
nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
40 Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò,
kí a sì tọ Olúwa lọ.
41 Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè
sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé:
42 “Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀
ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
43 “Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa;
ìwọ ń parun láìsí àánú.
44 Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ
pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
45 Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn
láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
46 “Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn
gbòòrò sí wa.
47 Àwa ti jìyà àti ìparun,
nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
48 Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò
nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
49 Ojú mi kò dá fún omijé,
láì sinmi,
50 títí ìgbà tí Olúwa yóò ṣíjú wolẹ̀
láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
51 Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi
nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
52 Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí
dẹ mí bí ẹyẹ.
53 Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò
wọ́n sì ju òkúta lù mí.
54 Orí mi kún fún omi,
mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
55 Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa,
láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
56 Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi: “Má ṣe di etí rẹ
sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
57 O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́,
o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
58 Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò,
o ra ẹ̀mí mi padà.
59 O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi
Gbé ẹjọ́ mi ró!
60 Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn,
gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
61 Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn
àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi—
62 Ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ
sí mi ní gbogbo ọjọ́.
63 Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde,
wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
64 Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn
fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
65 Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn,
kí o sì fi wọ́n ré.
66 Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú,
lábẹ́ ọ̀run Olúwa.
4 Báwo ni wúrà ṣe sọ ògo dídán rẹ̀ nù,
wúrà dídára di àìdán!
Òkúta ibi mímọ́ wá túká
sí oríta gbogbo òpópó.
2 Báwo ni àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin Sioni tí ó ṣe iyebíye,
tí wọ́n fi wúrà dídára ṣe
wá dàbí ìkòkò amọ̀ lásán
iṣẹ́ ọwọ́ amọ̀kòkò!
3 Àwọn ajáko pèsè ọmú wọn
fún ìtọ́jú àwọn ọmọ wọn,
ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi wá láì lọ́kàn
bí ògòǹgò ní aginjù.
4 Nítorí òǹgbẹ, ahọ́n àwọn ọmọ ọwọ́
lẹ̀ mọ́ òkè ẹnu wọn;
àwọn ọmọdé bẹ̀bẹ̀ fún oúnjẹ
Ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó fi fún wọn.
5 Àwọn tí ó ń jẹ ohun dáradára
di òtòṣì ní òpópó.
Àwọn tí a fi aṣọ dáradára wọ̀
ni wọ́n sùn ní orí òkìtì eérú.
6 Ìjìyà àwọn ènìyàn mi
tóbi ju ti Sodomu lọ,
tí a sí ní ipò ní òjijì
láìsí ọwọ́ láti ràn án lọ́wọ́.
7 Ọmọ ọba ọkùnrin wọn mọ́ ju òjò-dídì,
wọ́n sì funfun ju wàrà lọ
wọ́n ni ìtọ́jú bí iyùn pupa,
ìrísí wọn dàbí safire.
8 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí wọ́n dúdú ju èédú;
wọn kò sì dá wọn mọ̀ ní òpópó.
Ara wọn hun mọ́ egungun;
ó sì gbẹ bí igi gbígbẹ.
9 Àwọn tí ó kù nípasẹ̀ idà sàn
ju àwọn tí ìyàn pa;
tí ó wọ àkísà ebi, tí ó ń ṣòfò
fún àìní oúnjẹ láti inú pápá.
10 Pẹ̀lú ọwọ́ àwọn obìnrin aláàánú
ni wọ́n ṣe ọmọ wọn jẹ
tí ó di oúnjẹ fún wọn
nígbà tí a pa àwọn ènìyàn mi run.
11 Olúwa ti fi ihò kíkún fún ìbínú rẹ̀;
ó sì tú ìbínú gbígbóná rẹ̀ jáde.
Ó da iná ní Sioni
tí ó jó ìpìlẹ̀ rẹ̀ run.
12 Àwọn ọba ayé kò gbàgbọ́,
tàbí àwọn ènìyàn ayé,
wí pé àwọn ọ̀tá àti aninilára le wọ
odi ìlú Jerusalẹmu.
13 Èyí ṣẹlẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn wòlíì
àti àìṣedéédéé àwọn olórí àlùfáà,
tí ó ta ẹ̀jẹ̀ àwọn olódodo
sílẹ̀ láàrín rẹ̀.
14 Nísinsin yìí wọ́n ń rìn kiri ní òpópó
bí ọkùnrin tí ó fọ́jú.
Ẹ̀jẹ̀ ara wọn sọ wọ́n di àbàwọ́n
tí kò sẹ́ni tó láyà láti fọwọ́ kan aṣọ wọn.
15 “Lọ kúrò! Ẹ̀yin di aláìmọ́!” ni àwọn ènìyàn ń kígbe sí wọn.
“Ẹ lọ! Ẹ lọ! Ẹ má ṣe fọwọ́ kàn wá!”
Àwọn ènìyàn láàrín orílẹ̀-èdè wí pé,
“Wọn kì yóò tẹ̀dó síbí mọ́.”
16 Olúwa ti tú wọn ká fúnrarẹ̀;
kò sí bojútó wọn mọ́.
Kò sí ọ̀wọ̀ fún olórí àlùfáà mọ́,
àti àánú fún àwọn àgbàgbà.
17 Síwájú sí i, ojú wa kùnà
fún wíwo ìrànlọ́wọ́ asán;
láti orí ìṣọ́ wa ni à ń wò
fún orílẹ̀-èdè tí kò le gbà wá là.
18 Wọ́n ń ṣọ́ wa kiri,
àwa kò sì le rìn ní òpópó wa mọ́.
Òpin wa ti súnmọ́, ọjọ́ wa sì níye
nítorí òpin wa ti dé.
19 Àwọn tí ń lé wa yára
ju idì ojú ọ̀run lọ;
wọ́n lé wa ní gbogbo orí òkè
wọ́n sì gẹ̀gùn dè wá ní aginjù.
20 Ẹni ààmì òróró Olúwa, èémí ìyè wa,
ni wọ́n fi tàkúté wọn mú.
Àwa rò pé lábẹ́ òjìji rẹ̀
ni àwa yóò máa gbé láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
21 Ẹ yọ̀ kí inú yín sì dùn, ẹ̀yin ọmọbìnrin Edomu,
ẹ̀yin tó ń gbé ní ilẹ̀ Usi.
Ṣùgbọ́n, a ó gbé ago náà kọjá sọ́dọ̀ rẹ pẹ̀lú;
ìwọ yóò yó bí ọ̀mùtí, ìwọ yóò sì rìn ní ìhòhò.
22 Ìwọ ọmọbìnrin Sioni, ìjìyà rẹ yóò dópin;
kò ní mú ìgbèkùn rẹ pẹ́ mọ́.
Ṣùgbọ́n, ìwọ ọmọbìnrin Edomu, yóò jẹ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ní yà
yóò sì fi àìṣedéédéé rẹ hàn kedere.
5 Rántí, Olúwa, ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa;
wò ó, kí o sì rí ìtìjú wa.
2 Àwọn ohun ìní wa ti di ti àlejò,
ilé wa ti di ti àjèjì.
3 Àwa ti di aláìní òbí àti aláìní baba,
àwọn ìyá wa ti di opó.
4 A gbọdọ̀ ra omi tí à ń mu;
igi wa di títà fún wa.
5 Àwọn tí ó ń lé wa súnmọ́ wa;
àárẹ̀ mú wa àwa kò sì rí ìsinmi.
6 Àwa jọ̀wọ́ ara wa fún Ejibiti àti Asiria
láti rí oúnjẹ tó tó jẹ.
7 Àwọn baba wa ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣí mọ́,
àwa sì ń ru ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
8 Àwọn ẹrú ń jẹ ọba lórí wa,
kò sì ṣí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ wọn.
9 Àwa ń rí oúnjẹ wa nínú ewu ẹ̀mí wa
nítorí idà tí ó wà ní aginjù.
10 Ẹran-ara wa gbóná bí ààrò,
ebi sì yó wa bí àárẹ̀.
11 Wọ́n ti fipá bá àwọn obìnrin wa lòpọ̀ ní Sioni,
àti àwọn wúńdíá ti o wa ní ìlú Juda.
12 Àwọn ọmọ ọbakùnrin ti di síso sókè ní ọwọ́ wọn;
kò sí ìbọ̀wọ̀ fún àgbàgbà mọ́.
13 Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wa ru òkúta;
àwọn ọmọkùnrin sì ń ṣàárẹ̀ lábẹ́ ẹrù igi.
14 Àwọn àgbàgbà ti lọ kúrò ní ẹnu-bodè ìlú;
àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì dákẹ́ orin wọn
15 Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa;
ọ̀fọ̀ sì ti dúró bí ijó fún wa.
16 Adé ti ṣí kúrò ní orí wa
ègbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀.
17 Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa,
nítorí èyí, ojú wa sì ṣú.
18 Fún òkè Sioni tí ó ti di ahoro
lórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri.
19 Ìwọ, Olúwa, jẹ ọba títí láé;
ìjọba rẹ dúró láti ìran kan dé ìran mìíràn.
20 Kí ló dé tí o ń gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà?
Kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́?
21 Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, Olúwa, kí àwa kí ó le padà;
mú ọjọ́ wa di tuntun bí ìgbàanì
22 Àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá
tí ìbínú rẹ sí wa sì kọjá ìwọ̀n.
Ìpè sí ìforítì
19 Ará, ǹjẹ́ bí a ti ní ìgboyà láti wọ inú ibi mímọ́ nípasẹ̀ ẹ̀jẹ̀ Jesu, 20 nípa ọ̀nà títún àti ààyè, tí o yà sí mímọ́ fún wa, àti láti kọjá aṣọ ìkélé èyí yìí ní, ara rẹ̀; 21 àti bí a ti ni àlùfáà gíga lórí ilé Ọlọ́run; 22 ẹ jẹ́ kí a fi òtítọ́ ọkàn súnmọ́ tòsí ni ẹ̀kún ìgbàgbọ́, kí a sì wẹ ọkàn wa mọ́ kúrò nínú ẹ̀rí ọkàn búburú, kí a sì fi omi mímọ́ wẹ ara wa nù. 23 Ẹ jẹ́ kí a di ìjẹ́wọ́ ìrètí wa mu ṣinṣin ni àìṣiyèméjì; (nítorí pé olóòtítọ́ ní ẹni tí o ṣe ìlérí). 24 Ẹ jẹ́ kí a yẹ ara wa wò láti ru ara wa sí ìfẹ́ àti sí iṣẹ́ rere: 25 kí a ma máa kọ ìpéjọpọ̀ ara wa sílẹ̀, gẹ́gẹ́ bi àṣà àwọn ẹlòmíràn; ṣùgbọ́n kí a máa gba ara ẹni níyànjú pẹ̀lúpẹ̀lú bí ẹ̀yin ti rí i pé ọjọ́ náà ń súnmọ́ etílé.
26 Nítorí bí àwa ba mọ̀ ọ́n mọ̀ dẹ́ṣẹ̀ lẹ́yìn ìgbà tí àwa bá ti gba ìmọ̀ òtítọ́ kò tún sí ẹbọ fún ẹ̀ṣẹ̀ mọ́. 27 (A)Bí kò ṣe ìrètí ìdájọ́ tí ó ba ni lẹ́rù, àti ti ìbínú ti o múná, tí yóò pa àwọn ọ̀tá run. 28 (B)Ẹnikẹ́ni tí ó ba gan òfin Mose, ó kú láìsí àánú nípa ẹ̀rí ẹni méjì tàbí mẹ́ta: 29 (C)Mélòó mélòó ni ẹ rò pé a o jẹ ẹni náà ní ìyà kíkan, ẹni tí o tẹ ọmọ Ọlọ́run mọ́lẹ̀ tí ó sì ti ka ẹ̀jẹ̀ májẹ̀mú ti a fi sọ ọ́ di mímọ́ si ohun àìmọ́, tí ó sì ti kẹ́gàn ẹ̀mí oore-ọ̀fẹ́. 30 (D)Nítorí àwa mọ ẹni tí o wí pé: Ẹ̀san ni ti èmi, Olúwa wí pé, “Èmi ó gbẹ̀san.” Àti pẹ̀lú, “Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀.” 31 Ohun ẹ̀rù ni láti ṣubú sí ọwọ́ Ọlọ́run alààyè.
32 Ṣùgbọ́n ẹ rántí ọjọ́ ìṣáájú nínú èyí tí, nígbà tí a ti sí yin lójú, ẹ fi ara da wàhálà ńlá ti ìjìyà; 33 lápákan, nígbà tí a sọ yín di ìran wíwò nípa ẹ̀gàn àti ìpọ́njú; àti lápákan, nígbà tí ẹ̀yin di ẹgbẹ́ àwọn tí a ṣe bẹ́ẹ̀ si. 34 Nítorí ẹ̀yin bá àwọn tí ó wà nínú ìdè kẹ́dùn, ẹ sì fi ayọ̀ gba ìkólọ ẹrù yin, nítorí ẹ̀yin mọ nínú ara yin pé, ẹ ni ọrọ̀ tí ó wà títí, tí ó sì dára jù bẹ́ẹ̀ lọ. 35 Nítorí náà ẹ má ṣe gbé ìgboyà yín sọnù, èyí ti o ni èrè ńlá.
36 Nítorí ẹ̀yin kò le ṣe aláìní sùúrù, nítorí ìgbà tí ẹ̀yin bá ti ṣe ìfẹ́ Ọlọ́run tan kí ẹ̀yin le gba ìlérí náà. 37 (E)Nítorí,
“Ni ìwọ̀n ìgbà díẹ̀ sí i,
ẹni náà ti ń bọ̀ yóò dé,
kí yóò sì jáfara.
38 Ṣùgbọ́n,
“Olódodo ni yóò yè nípa ìgbàgbọ́.
Ṣùgbọ́n bí o ba fàsẹ́yìn,
ọkàn mi kò ní inú dídùn sí i.”
39 Ṣùgbọ́n àwa kò sí nínú àwọn tí ń fàsẹ́yìn sínú ègbé; bí kò ṣe nínú àwọn tí o gbàgbọ́ sí ìgbàlà ọkàn.
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.