Old/New Testament
Àṣọtẹ́lẹ̀ ní tí Moabu
48 (A)Ní ti Moabu:
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí:
“Ègbé ni fún Nebo nítorí a ó parun.
A dójútì Kiriataimu, a sì mú un,
ojú yóò ti alágbára, a ó sì fọ́nká.
2 Moabu kò ní ní ìyìn mọ́,
ní Heṣboni ni wọn ó pète ìparun rẹ̀,
‘Wá, kí a pa orílẹ̀-èdè náà run.’
Àti ẹ̀yin òmùgọ̀ ọkùnrin pàápàá ni a ó pa lẹ́nu mọ́,
a ó fi idà lé e yín.
3 Gbọ́ igbe ní Horonaimu,
igbe ìrora àti ìparun ńlá.
4 Moabu yóò di wíwó palẹ̀;
àwọn ọmọdé rẹ̀ yóò kígbe síta.
5 Wọ́n gòkè lọ sí Luhiti,
wọ́n ń sọkún kíkorò bí wọ́n ti ń lọ;
ní ojú ọ̀nà sí Horonaimu
igbe ìrora ìparun ni à ń gbọ́ lọ.
6 Sá! Àsálà fún ẹ̀mí yín;
kí ẹ sì dàbí aláìní ní aginjù.
7 Níwọ́n ìgbà tí o gbẹ́kẹ̀lé agbára àti ọrọ̀ rẹ,
a ó kó ìwọ náà ní ìgbèkùn,
Kemoṣi náà yóò lọ sí ilẹ̀ ìgbèkùn
pẹ̀lú àlùfáà àti àwọn aláṣẹ rẹ̀.
8 Gbogbo ìlú rẹ ni apanirun yóò dojúkọ,
ìlú kan kò sì ní le là.
Àfonífojì yóò di ahoro
àti ilẹ̀ títẹ́ ni a ó run,
nítorí tí Olúwa ti sọ̀rọ̀.
9 Fi iyọ̀ sí Moabu,
nítorí yóò ṣègbé,
àwọn ìlú rẹ yóò sì di ahoro
láìsí ẹni tí yóò gbé inú rẹ̀.
10 “Ìfibú ni fún ẹni tí ó fi ìmẹ́lẹ́ ṣe iṣẹ́ Olúwa,
ìfibú ni fún ẹni tí ó pa idà mọ́ fún ìtàjẹ̀ sílẹ̀.
11 “Moabu ti wà ní ìsinmi láti ìgbà èwe rẹ̀ wá
bí i ọtí wáìnì lórí gẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀ rẹ̀,
tí a kò dà láti ìgò kan sí èkejì
kò tí ì lọ sí ilẹ̀ ìgbèkùn rí.
Ó dùn lẹ́nu bí ó ti yẹ,
òórùn rẹ̀ kò yí padà.
12 Ṣùgbọ́n ọjọ́ ń bọ̀,”
ni Olúwa wí,
“nígbà tí n ó rán àwọn tí ó n da ọtí láti inú àwọn ìgò
tí wọ́n ó sì dà á síta;
Wọn ó sọ àwọn ìgò rẹ̀ di òfo,
wọn ó sì fọ́ àwọn ife rẹ̀.
13 Nígbà náà Moabu yóò sì tú u nítorí Kemoṣi,
bí ojú ti í ti ilé Israẹli
nígbà tí ó gbẹ́kẹ̀lé Beteli.
14 “Báwo ni o ṣe lè sọ pé, ‘ajagun ni wá,
alágbára ní ogun jíjà’?
15 A ó pa Moabu run, a ó sì gba àwọn ìlú rẹ̀;
a ó sì dúńbú àwọn arẹwà ọkùnrin rẹ̀,”
ni ọba wí, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
16 “Ìṣubú Moabu súnmọ́;
ìpọ́njú yóò dé kánkán.
17 Ẹ dárò fún, gbogbo ẹ̀yin tí ó yí i ká
gbogbo ẹ̀yin tí ẹ mọ bí ó ti ní òkìkí tó.
Ẹ sọ pé, ‘Báwo ni ọ̀pá agbára rẹ
títóbi tí ó sì lógo ṣe fọ́!’
18 “Sọ̀kalẹ̀ níbi ògo rẹ,
kí o sì jókòó ní ilẹ̀ gbígbẹ,
ẹ̀yin olùgbé ọmọbìnrin Diboni,
nítorí tí ẹni tí ó pa Moabu run
yóò dojúkọ ọ́
yóò sì pa àwọn ìlú olódi rẹ run.
19 Dúró lẹ́bàá ọ̀nà kí o sì wòran,
ìwọ tí ń gbé ní Aroeri.
Bí ọkùnrin tí ó sálọ àti obìnrin tí ó ń sá àsálà
‘kí ni ohun tí ó ṣẹlẹ̀?’
20 Ojú ti Moabu nítorí tí a wó o lulẹ̀.
Ẹ hu, kí ẹ sì kígbe!
Ẹ kéde rẹ̀ ní Arnoni pé,
a pa Moabu run.
21 Ìdájọ́ ti dé sí àwọn òkè pẹrẹsẹ
sórí Holoni, Jahisa àti Mefaati,
22 sórí Diboni, Nebo àti Beti-Diblataimu
23 sórí Kiriataimu, Beti-Gamu àti Beti-Meoni,
24 sórí Kerioti àti Bosra,
sórí gbogbo ìlú Moabu, nítòsí àti ní ọ̀nà jíjìn.
25 A gé ìwo Moabu kúrò,
apá rẹ̀ dá,”
ni Olúwa wí.
26 “Ẹ jẹ́ kí a mú u mutí
nítorí ó kó ìdọ̀tí bá Olúwa,
jẹ́ kí Moabu lúwẹ̀ẹ́ nínú èébì rẹ̀,
kí ó di ẹni ẹ̀gàn.
27 Ǹjẹ́ Israẹli kò di ẹni ẹ̀gàn rẹ?
Ǹjẹ́ a kó o pẹ̀lú àwọn olè
tó bẹ́ẹ̀ tí o ń gbọn orí rẹ̀ pẹ̀lú yẹ̀yẹ́
nígbàkúgbà bí a bá sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀?
28 Kúrò ní àwọn ìlú rẹ, kí o sì máa gbé láàrín àwọn òkúta,
ẹ̀yin tí ó ti ń gbé inú ìlú Moabu.
Ẹ dàbí i àdàbà tí ó kọ́ ìtẹ́ rẹ̀
sí ẹnu ihò.
29 “A ti gbọ́ nípa ìgbéraga Moabu:
àti ìwà mo gbọ́n tan rẹ̀
àti ìgbéraga ọkàn rẹ̀.
30 Mo mọ àfojúdi rẹ̀, ṣùgbọ́n òfo ni,”
ni Olúwa wí,
“ìfọ́nnu rẹ̀ kò lè ṣe nǹkan kan.
31 Nítorí náà, mo pohùnréré
ẹkún lórí Moabu fún àwọn
ará Moabu ni mo kígbe lóhùn rara
Mo kẹ́dùn fún àwọn ọkùnrin Kiri-Hareseti.
32 Mo sọkún fún ọ bí Jaseri ṣe sọkún
ìwọ àjàrà Sibma.
Ẹ̀ka rẹ tẹ̀ títí dé Òkun,
wọn dé Òkun Jaseri.
Ajẹnirun ti kọlu èso rẹ,
ìkórè èso àjàrà rẹ.
33 Ayọ̀ àti ìdùnnú ti kúrò
nínú ọgbà àjàrà àti oko Moabu.
Mo dá ọwọ́ ṣíṣàn ọtí wáìnì dúró lọ́dọ̀ olùfúntí;
kò sí ẹni tí ó ń tẹ̀ wọ́n pẹ̀lú igbe ayọ̀
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé igbe wà,
wọn kì í ṣe igbe ti ayọ̀.
34 “Ohùn igbe wọn gòkè
láti Heṣboni dé Eleale àti Jahasi,
láti Soari títí dé Horonaimu àti Eglati-Ṣeliṣi,
nítorí àwọn omi Nimrimu pẹ̀lú yóò gbẹ
35 Ní ti Moabu ni èmi yóò ti fi òpin sí
ẹni tí ó rú ẹbọ ní ibí gíga
àti ẹni tí ń sun tùràrí fún òrìṣà rẹ̀,”
ni Olúwa wí.
36 “Nítorí náà ọkàn mi ró fún Moabu bí fèrè,
ọkàn mi ró bí fèrè fún àwọn ọkùnrin Kiri-Hareseti.
Nítorí ìṣúra tí ó kójọ ṣègbé.
37 Gbogbo orí ni yóò pá,
gbogbo irùngbọ̀n ni a ó gé kúrò,
gbogbo ọwọ́ ni a sá lọ́gbẹ́,
àti aṣọ ọ̀fọ̀ ní gbogbo ẹ̀gbẹ́.
38 Ẹkún ńlá ní yóò wà lórí gbogbo òrùlé Moabu,
àti ní ìta rẹ̀,
nítorí èmi ti fọ́ Moabu
bí a ti ń fọ́ ohun èlò tí kò wu ni,”
ni Olúwa wí.
39 “Èéṣe tí ẹ fi fọ́ túútúú,
tí ẹ sì fi ń pohùnréré ẹkún!
Báwo ni Moabu ṣe yí
ẹ̀yìn padà ní ìtìjú!
Moabu ti di ẹni ìtìjú àti ẹ̀gàn àti
ìdààmú sí gbogbo àwọn tí ó yìí ká.”
40 Báyìí ni Olúwa wí:
“Wò ó ẹyẹ idì náà ń fò bọ̀ nílẹ̀
ó sì na ìyẹ́ rẹ̀ lórí Moabu.
41 Kerioti ni a ó kó lẹ́rú àti ilé agbára ni ó gbà
Ní ọjọ́ náà ọkàn àwọn akọni Moabu
yóò dàbí ọkàn obìnrin tí ó ń rọbí.
42 A ó pa Moabu run gẹ́gẹ́ bí
orílẹ̀-èdè nítorí pé ó gbéraga sí Olúwa.
43 Ẹ̀rù àti ọ̀fìn àti okùn dídè
ń dúró dè yín, ẹ̀yin ènìyàn Moabu,”
ní Olúwa wí.
44 “Ẹnikẹ́ni tí ó bá sá fún
ẹ̀rù yóò ṣubú sínú ọ̀fìn
ẹnikẹ́ni tí o bá jáde síta
nínú ọ̀fìn ní à ó mú
nínú okùn dídè nítorí tí
èmi yóò mú wá sórí
Moabu àní ọdún ìjìyà rẹ,”
ní Olúwa wí.
45 “Ní abẹ́ òjìji Heṣboni
àwọn tí ó sá dúró láìní agbára,
nítorí iná ti jáde wá láti Heṣboni,
àti ọwọ́ iná láti àárín Sihoni,
yóò sì jó iwájú orí Moabu run,
àti agbárí àwọn ọmọ aláriwo.
46 Ègbé ní fún ọ Moabu!
Àwọn ènìyàn orílẹ̀-èdè Kemoṣi ṣègbé
a kó àwọn ọmọkùnrin rẹ lọ sí ilẹ̀ àjèjì
àti àwọn ọmọbìnrin rẹ lọ sí ìgbèkùn.
47 “Síbẹ̀, èmi yóò dá ìkólọ
Moabu padà ní ọjọ́ ìkẹyìn,”
ni Olúwa wí.
Eléyìí ní ìdájọ́ ìkẹyìn lórí Moabu.
Àṣọtẹ́lẹ̀ ní tí Ammoni
49 (B)Ní ti Ammoni:
Báyìí ni Olúwa wí:
“Israẹli kò ha ní ọmọkùnrin?
Israẹli kò ha ní àrólé bí?
Nítorí kí ni Malkomu ṣe jogún Gadi?
Kí ló dé tí àwọn ènìyàn rẹ̀ ń gbé ìlú rẹ̀?
2 Ṣùgbọ́n ọjọ́ náà ń bọ̀,”
ni Olúwa wí;
“nígbà tí èmi yóò mú kí a gbọ́ ìdágìrì ogun ní Rabba
tí Ammoni yóò sì di òkìtì ahoro,
gbogbo ìlú tí ó yí i ká ni a ó jó níná.
Nígbà náà ni Israẹli yóò
lé wọn, àwọn tí ó ti lé e jáde,”
ni Olúwa wí.
3 “Hu, ìwọ Heṣboni
nítorí Ai tí rún,
kígbe ẹ̀yin olùgbé Rabba!
Ẹ wọ aṣọ ọ̀fọ̀ kí ẹ sì ṣọ̀fọ̀.
Ẹ sáré sókè sódò nínú ọgbà,
nítorí Malkomu yóò lọ sí ìgbèkùn
pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti ìjòyè rẹ̀.
4 Èéṣe tí ìwọ fi ń ṣògo nínú Àfonífojì rẹ,
ṣògo nínú Àfonífojì rẹ fún èso?
Ẹ̀yin ọmọbìnrin Ammoni aláìṣòótọ́,
ẹ gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ yín, ẹ sì wí pé,
‘ta ni yóò kò mí lójú?’
5 Èmi yóò mu ẹ̀rù wá lórí rẹ
láti ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tó yí ọ ká,”
ni Olúwa, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
6 “Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
Gbogbo yín ni ó lé jáde, kò sì ṣí ẹnìkan
tí yóò dá ìkólọ Ammoni padà,”
ni Olúwa wí.
Àsọtẹ́lẹ̀ Ní ti Edomu
7 (C)Nípa Edomu:
Èyí ní ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí:
“Ṣe kò ha sí ọgbọ́n mọ́ ni Temani?
Ṣé a ti ké ìmọ̀ràn kúrò ní ọ̀dọ̀ olóyè?
Ṣé ọgbọ́n wọn ti bàjẹ́ bí?
8 Yípadà kí o sálọ, sápamọ́ sínú ihò,
ìwọ tí ó ń gbé ní Dedani,
nítorí èmi yóò mú ibi wá sórí Esau,
ní àkókò tí èmi ó bẹ̀ ẹ́ wò.
9 Tí àwọn tí ń ṣa èso bá tọ̀ ọ́ wá;
ǹjẹ́ wọn kò ní fi èso díẹ̀ sílẹ̀?
Tí olè bá wá ní òru; ǹjẹ́ wọn kò ní
kó gbogbo ohun tí wọ́n bá fẹ́?
10 Ṣùgbọ́n èmi yóò tu Esau sí ìhòhò,
èmi ti fi ibi ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ hàn,
nítorí kí o máa ba à fi ara rẹ pamọ́.
Àwọn ọmọ rẹ, ẹbí rẹ àti
àwọn ará ilé rẹ yóò parun.
Wọn kò sì ní sí mọ́.
11 Fi àwọn ọmọ aláìní baba sílẹ̀
èmi yóò dáàbò bo ẹ̀mí wọn.
Àwọn opó rẹ gan an lè gbẹ́kẹ̀lé mi.”
12 Èyí ni ohun tí Olúwa wí bí ẹnikẹ́ni tí kò bá yẹ kí ó mu ago náà bá mú un, kí ló dé tí ìwọ yóò fi lọ láìjìyà? Ìwọ kò ní lọ láìjìyà; ṣùgbọ́n ìwọ yóò mú un. 13 Èmi fi ara mi búra ni Olúwa wí, wí pé, “Bosra yóò ba ayé ara rẹ̀ jẹ́. Yóò di ẹni ẹ̀gàn, ẹni èpè àti ẹni ègún, àti gbogbo ìlú rẹ̀ yóò di ìbàjẹ́ títí láé.”
14 Ní gbígbọ́, èmi ti gbọ́ ìró kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa:
A rán ikọ̀ kan sí orílẹ̀-èdè pé,
Ẹ kó ara yín jọ, ẹ wá sórí rẹ̀, ẹ sì dìde láti jagun.
15 “Ní báyìí, èmi yóò sọ ọ́ di
kékeré láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo;
ẹni ẹ̀gàn láàrín àwọn ènìyàn.
16 Ìpayà tí ìwọ ti fà sínú
ìgbéraga ọkàn rẹ sì ti tàn ọ́ jẹ;
ìwọ tí ń gbé ní pàlàpálá àpáta,
tí o jókòó lórí ìtẹ́ gíga
síbẹ̀ o kọ́ ìtẹ́ rẹ ga gẹ́gẹ́ bí ẹyẹ idì;
láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti mú ọ sọ̀kalẹ̀ wá,”
ni Olúwa wí.
17 “Edomu yóò di ahoro
gbogbo àwọn tí ń kọjá yóò jáyà, wọn ó sì
fi rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà nítorí gbogbo ìpalára rẹ
18 Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe gba Sodomu
àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú
tí ó wà ní àyíká rẹ,”
ní Olúwa wí.
“Bẹ́ẹ̀ ni, kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé níbẹ̀;
kò sì ní sí ènìyàn tí yóò tẹ̀dó síbẹ̀ mọ́.
19 “Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá,
Èmi ó lé Edomu kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá.
Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀?
Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí?
Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”
20 Nítorí náà, ẹ gbọ́ ohun tí
Olúwa ní fún Edomu, ohun tí
ó ní ní pàtàkì fún àwọn tí ń gbé ní Temani.
Àwọn ọ̀dọ́ àgbò ni à ó lé jáde.
Pápá oko wọn ni yóò run nítorí wọn.
21 Ilẹ̀ yóò mì tìtì nípa ariwo ìṣubú wọn,
a ó gbọ́ igbe wọn
ní Òkun pupa.
22 Wò ó! Ẹyẹ idì yóò gòkè fò wálẹ̀,
yóò tẹ ìyẹ́ rẹ̀ lórí Bosra.
Ní ọjọ́ náà ọkàn àwọn ajagun
Edomu yóò dàbí ọkàn obìnrin tí ń rọbí.
Àsọtẹ́lẹ̀ kan nípa Damasku
23 Nípa Damasku,
“Inú Hamati àti Arpadi bàjẹ́ nítorí wọ́n gbọ́ ìròyìn búburú, ìjayà dé bá wọn,
wọ́n sì dààmú bí omi Òkun.
24 Damasku di aláìlera, ó pẹ̀yìndà
láti sálọ, ìwárìrì sì dé bá a,
ìbẹ̀rù àti ìrora dìímú, ìrora
bí ti obìnrin tí ó wà ní ipò ìrọbí.
25 Kí ló dé tí ìlú olókìkí di ohun ìkọ̀sílẹ̀;
ìlú tí mo dunnú sí.
26 Lóòtítọ́, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ
yóò ṣubú lójú pópó, gbogbo
àwọn ọmọ-ogun rẹ yóò pa
ẹnu mọ́ ní ọjọ́ náà,”
ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
27 “Èmi yóò fi iná sí odi Damasku,
yóò sì jó gbọ̀ngàn Beni-Hadadi run.”
Ọ̀rọ̀ nípa Kedari àti Hasori
28 Nípa Kedari àti ìjọba Hasori èyí ti Nebukadnessari ọba Babeli dojú ìjà kọ:
Èyí ni ohun tí Olúwa sọ:
“Dìde kí o sì dojú ìjà kọ Kedari,
kí o sì pa àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn run.
29 (D)Àgọ́ wọn àti agbo àgùntàn wọn ni wọn ó kó lọ;
àgọ́ wọn yóò di ìṣínípò padà
pẹ̀lú gbogbo ẹrù àti ìbákasẹ wọn.
Àwọn ènìyàn yóò ké sórí wọ́n pé;
‘Ẹ̀rù yí káàkiri!’
30 “Sálọ kíákíá!
Fi ara pamọ́ sí ibi jíjìn, ẹ̀yin olùgbé Hasori,”
ni Olúwa wí.
“Nebukadnessari ọba Babeli ti dojú ìjà kọ ọ́.
31 “Dìde kí o sì dojú ìjà kọ orílẹ̀-èdè tí ó wà nínú ìrọ̀rùn,
èyí tí ó gbé ní àìléwu,”
ní Olúwa wí.
“Orílẹ̀-èdè tí kò ní odi tàbí irin,
àwọn ènìyàn rẹ̀ ń dágbé.
32 Àwọn ìbákasẹ á di ẹrù
àti àwọn ẹran ọ̀sìn, wọ́n á di ìkógun.
Èmi yóò tú àwọn tí ó wà ní òkèèrè sí inú afẹ́fẹ́.
Èmi yóò sì mú ibi wá sí àyíká gbogbo,”
báyìí ní Olúwa wí.
33 “Hasori yóò di ibi ìdọdẹ àwọn
akátá, ibi ìkọ̀sílẹ̀ ayérayé,
kò sí ẹni tí yóò gbé ní ibẹ̀.”
Àṣọtẹ́lẹ̀ ní ti Elamu
34 Èyí ní ọ̀rọ̀ Olúwa èyí tí ó tọ Jeremiah wòlíì wá nípa Elamu ní ìbẹ̀rẹ̀ ìjọba Sedekiah ọba Juda:
35 Èyí ni ohun tí Ọlọ́run alágbára sọ:
“Wò ó, èmi yóò fọ́ ìtẹ̀gùn Elamu,
ẹni tí wọ́n sinmi lé nípa agbára.
36 Èmi yóò mú kí afẹ́fẹ́ orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin
àgbáyé lòdì sí Elamu.
Èmi yóò tú wọn ká sí ìpín afẹ́fẹ́ mẹ́rin
àti pé, kò sí orílẹ̀-èdè tí ilẹ̀ àjèjì Elamu kò ní lọ.
37 Èmi yóò kẹ́gàn Elamu níwájú àwọn ọ̀tá wọn,
àti níwájú àwọn tí wọ́n ń wá ẹ̀mí wọn;
Èmi yóò mú ibi wá sí orí wọn,
àní, ìbínú gbígbóná mi,”
bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí.
“Èmi yóò lé wọn pẹ̀lú idà, di ìgbà tí èmi yóò rẹ́yìn wọn.
38 Èmi yóò sì gbé ìtẹ́ mi kalẹ̀ ní Elamu,
èmí yóò sì pa ọba wọn àti ìjòyè wọn run,”
báyìí ni Olúwa wí.
39 “Síbẹ̀, èmi yóò dá ìkólọ
Elamu padà láìpẹ́ ọjọ́,”
báyìí ni Olúwa wí.
Melkisedeki jẹ́ àlùfáà
7 (A)Nítorí Melkisedeki yìí, ọba Salẹmu, àlùfáà Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo, ẹni tí ó pàdé Abrahamu bí ó ti ń padà bọ̀ láti ibi pípa àwọn ọba, tí ó sì súre fún un, 2 ẹni tí Abrahamu sì pín ìdámẹ́wàá ohun gbogbo fún. Ní ọ̀nà èkínní orúkọ rẹ̀ túmọ̀ sí “ọba òdodo,” àti lẹ́yìn náà pẹ̀lú, “ọba Salẹmu,” tí í ṣe “ọba àlàáfíà.” 3 Láìní baba, láìní ìyá, láìní ìtàn ìran, bẹ́ẹ̀ ni kò ní ìbẹ̀rẹ̀ ọjọ́ tàbí òpin ọjọ́ ayé; ṣùgbọ́n a ṣe é bí ọmọ Ọlọ́run; ó wà ní àlùfáà títí.
4 Ǹjẹ́ ẹ gbà á rò bí ọkùnrin yìí ti pọ̀ tó, ẹni tí Abrahamu baba ńlá fi ìdámẹ́wàá nínú àwọn àṣàyàn ìkógun fún. 5 Àti nítòótọ́ àwọn tí ó jẹ́ ọmọ Lefi, tí o gba oyè àlùfáà, wọ́n ní àṣẹ láti máa gba ìdámẹ́wàá lọ́wọ́ àwọn ènìyàn gẹ́gẹ́ bí òfin, èyí yìí, lọ́wọ́ àwọn arákùnrin wọn, bí ó tilẹ̀ ti jẹ́ pé, wọn ti inú Abrahamu jáde. 6 Ṣùgbọ́n òun ẹni tí a kò tilẹ̀ pìtàn ìran rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ wọn wá, gba ìdámẹ́wàá lọ́wọ́ Abrahamu, ó sì súre fún ẹni tí ó gba ìlérí, 7 láìsí ìjiyàn rárá ẹni kò tó ẹni tí à ń súre fún láti ọ̀dọ̀ ẹni tí ó ju ni. 8 Ni apá kan, àwọn ẹni kíkú gba ìdámẹ́wàá; ṣùgbọ́n níbẹ̀, ẹni tí a jẹ́rìí rẹ̀ pé o ń bẹ láààyè nì. 9 Àti bí a ti lè wí, Lefi pàápàá tí ń gba ìdámẹ́wàá, ti san ìdámẹ́wàá nípasẹ̀ Abrahamu. 10 Nítorí o sá à sì ń bẹ ní inú baba rẹ̀, nígbà ti Melkisedeki pàdé rẹ̀.
Jesu fẹ́ràn Melkisedeki
11 (B)Ǹjẹ́ ìbá ṣe pé pípé ń bẹ nípa oyè àlùfáà Lefi, (nítorí pé lábẹ́ rẹ̀ ni àwọn ènìyàn gba òfin), kín ni ó sì tún kù mọ́ tí àlùfáà mìíràn ìbá fi dìde ní títẹ̀lé àpẹẹrẹ tí Melkisedeki, tí a kò si wí pé ní títẹ̀lé àpẹẹrẹ tí Aaroni? 12 Nítorí pé bí a ti ń pààrọ̀ iṣẹ́ àlùfáà, a kò sì lè ṣàì máa pààrọ̀ òfin. 13 Nítorí ẹni tí à ń sọ̀rọ̀ nǹkan wọ̀nyí nípa rẹ̀ jẹ́ ẹ̀yà mìíràn, láti inú èyí tí ẹnikẹ́ni kò tì jọ́sìn rí níbi pẹpẹ. 14 Nítorí ó hàn gbangba pé láti inú ẹ̀yà Juda ni Olúwa wa ti dìde; nípa ẹ̀yà yìí Mose kò sọ ohunkóhun ní ti àwọn àlùfáà. 15 Ó sì tún hàn gbangba ju bẹ́ẹ̀ lọ bí ó ti jẹ pé àlùfáà mìíràn dìde ní àpẹẹrẹ ti Melkisedeki. 16 Èyí tí a fi jẹ́, kì í ṣe gẹ́gẹ́ bí ìlànà òfin nípa ti ara, bí kò ṣe nípa agbára ti ìyè àìlópin. 17 Nítorí a jẹ́rìí pé:
“Ìwọ ni àlùfáà títí láé
ní ipasẹ̀ ti Melkisedeki.”
18 Nítorí a mú òfin ìṣáájú kúrò nítorí àìlera àti àìlérè rẹ̀. 19 (Nítorí òfin kò mú ohunkóhun pé), a sì mú ìrètí tí ó dára jù wá nípa èyí tí àwa ń súnmọ́ Ọlọ́run.
20 Níwọ́n bí ó sì ti ṣe pé kì í ṣe ní àìbúra ni. Nítorí àwọn àlùfáà tẹ́lẹ̀ jẹ oyè láìsí ìbúra, 21 ṣùgbọ́n ti òun jẹ́ pẹ̀lú ìbúra nígbà tí Ọlọ́run wí fún un pé,
“Olúwa búra,
kí yóò sì yí padà:
‘Ìwọ ni àlùfáà kan títí láé ni ipasẹ̀ ti Mekisédékì.’ ”
22 Níwọ́n bẹ́ẹ̀ ni Jesu ti di onígbọ̀wọ́ májẹ̀mú tí ó dára jù.
23 Àti nítòótọ́ àwọn púpọ̀ ní a ti fi jẹ àlùfáà, nítorí wọn kò lè wà títí nítorí ikú. 24 Ṣùgbọ́n òun, nítorí tí o wà títí láé, ó ní oyè àlùfáà tí a kò lè rọ̀ ní ipò. 25 Nítorí náà ó sì le gbà wọ́n là pẹ̀lú títí dé òpin, ẹni tí ó bá tọ Ọlọ́run wá nípasẹ̀ rẹ̀, nítorí tí o ń bẹ láààyè títí láé láti máa bẹ̀bẹ̀ fún wọn.
26 Nítorí pé irú olórí àlùfáà bẹ́ẹ̀ ni o yẹ wá, mímọ́, àìlẹ́gàn, àìléèérí, tí a yà sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀, tí a sì gbéga ju àwọn ọ̀run lọ; 27 Ẹni tí kò ní láti máa rú ẹbọ lójoojúmọ́, bí àwọn olórí àlùfáà, fún ẹ̀ṣẹ̀ ti ara rẹ̀ náà, àti lẹ́yìn náà fún tí àwọn ènìyàn; nítorí èyí ni tí ó ṣe lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo, nígbà tí ó fi ara rẹ̀ rú ẹbọ. 28 Nítorí pé òfin a máa fi àwọn ènìyàn tí ó ní àìlera jẹ olórí àlùfáà; ṣùgbọ́n nípa ọ̀rọ̀ ti ìbúra, tí ó ṣe lẹ́yìn òfin, ó fi ọmọ jẹ; ẹni tí a sọ di pípé títí láé.
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.