Print Page Options
Previous Prev Day Next DayNext

Chronological

Read the Bible in the chronological order in which its stories and events occurred.
Duration: 365 days
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Version
Jobu 32-34

Ọ̀rọ̀ Elihu

32 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí dákẹ́ láti dá Jobu lóhùn, nítorí ó ṣe olódodo lójú ara rẹ̀. Nígbà náà ni inú bí Elihu ọmọ Barakeli ará Busi, láti ìbátan ìdílé Ramu; ó bínú si Jobu nítorí ti ó dá ara rẹ̀ láre kàkà ki ó dá Ọlọ́run láre. Inú sì bí i sí àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ mẹ́tẹ̀ẹ̀ta, nítorí tí wọn kò rí ọ̀nà láti dá Jobu lóhùn bẹ́ẹ̀ ni wọ́n dá Jobu lẹ́bi. Ǹjẹ́ Elihu ti dúró títí tí Jobu fi sọ̀rọ̀ tán nítorí tí àwọn wọ̀nyí dàgbà ju òun lọ ní ọjọ́ orí. Nígbà tí Elihu rí i pé ìdáhùn ọ̀rọ̀ kò sí ní ẹnu àwọn ọkùnrin mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí nígbà náà ni ó bínú.

Elihu, ọmọ Barakeli, ará Busi, dáhùn ó sì wí pé:

“Ọmọdé ni èmi,
    àgbà sì ní ẹ̀yin;
ǹjẹ́ nítorí náà ní mo dúró,
    mo sì ń bẹ̀rù láti fi ìmọ̀ mi hàn yin.
Èmi wí pé ọjọ́ orí ni ìbá sọ̀rọ̀,
    àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún ní ìbá kọ́ ni ní ọgbọ́n.
Ṣùgbọ́n ẹ̀mí kan ní ó wà nínú ènìyàn
    àti ìmísí Olódùmarè ní ì sì máa fún wọn ní òye.
Ènìyàn ńláńlá kì í ṣe ọlọ́gbọ́n,
    Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àgbà ní òye ẹ̀tọ́ kò yé.

10 “Nítorí náà ní èmí ṣe wí pé: Ẹ dẹtí sílẹ̀ sí mi;
    èmí pẹ̀lú yóò fi ìmọ̀ mi hàn.
11 Kíyèsi i, èmí ti dúró de ọ̀rọ̀ yín;
    Èmi fetísí àròyé yín,
nígbà tí ẹ̀yin ń wá ọ̀rọ̀ ti ẹ̀yin yóò sọ;
12     àní, mo fiyèsí yín tinútinú.
Sì kíyèsi i, kò sí ẹnìkan nínú yín tí ó le já Jobu ní irọ́;
    tàbí tí ó lè dá a lóhùn àríyànjiyàn rẹ̀!
13 Kí ẹ̀yin kí ó má ṣe wí pé, ‘Àwa wá ọgbọ́n ní àwárí;
    Ọlọ́run ni ó lè bì í ṣubú kì í ṣe ènìyàn.’
14 Bí òun kò ti sọ̀rọ̀ sí mi,
    bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò fi ọ̀rọ̀ yín dá a lóhùn.

15 “Ẹnu sì yà wọ́n, wọn kò sì dáhùn mọ́,
    wọ́n ṣíwọ́ ọ̀rọ̀ í sọ.
16 Mo sì retí, nítorí wọn kò sì fọhùn, wọ́n dákẹ́ jẹ́ẹ́;
    wọn kò sì dáhùn mọ́.
17 Bẹ́ẹ̀ ni èmí ó sì dáhùn nípa ti èmi,
    èmí pẹ̀lú yóò sì fi ìmọ̀ mi hàn.
18 Nítorí pé èmi kún fún ọ̀rọ̀ sísọ,
    ẹ̀mí ń rọ̀ mi ni inú mi.
19 Kíyèsi i, ikùn mi dàbí ọtí wáìnì, tí kò ní ojú-ìhò;
    ó múra tán láti bẹ́ bí ìgò-awọ tuntun.
20 Èmí ó sọ, kí ara kí ó le rọ̀ mí,
    èmí ó sí ètè mi, èmí ó sì dáhùn.
21 Lóòtítọ́ èmi kì yóò ṣe ojúsàájú sí ẹnìkankan,
    bẹ́ẹ̀ ni èmí kì yóò sì ṣe ìpọ́nni fún ẹnìkan.
22 Nítorí pé èmí kò mọ̀ ọ̀rọ̀ ìpọ́nni í sọ ní ṣíṣe bẹ́ẹ̀,
    Ẹlẹ́dàá mi yóò mú mi kúrò lọ́gán.

Elihu bá Jobu sọ̀rọ̀

33 “Ǹjẹ́ nítorí náà, Jobu, èmí bẹ̀ ọ,
    gbọ́ ọ̀rọ̀ mi kí o sì fetísí ọ̀rọ̀ mi!
Kíyèsi i nísinsin yìí, èmí ya ẹnu mi,
    ahọ́n mi sì sọ̀rọ̀ ní ẹnu mi.
Ọ̀rọ̀ mi yóò sì jásí ìdúró ṣinṣin ọkàn mi,
    ètè mi yóò sì sọ ìmọ̀ mi jáde dájúdájú.
Ẹ̀mí Ọlọ́run ni ó tí dá mi,
    àti ìmísí Olódùmarè ni ó ti fún mi ní ìyè.
Bí ìwọ bá le dá mi lóhùn,
    tò ọ̀rọ̀ rẹ̀ lẹ́sẹẹsẹ níwájú mi;
Kíyèsi i, bí ìwọ ṣe jẹ́ ti Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni èmi náà;
    láti amọ̀ wá ni a sì ti dá mi pẹ̀lú.
Kíyèsi i, ẹ̀rù ńlá mi kì yóò bà ọ;
    bẹ́ẹ̀ ni ọwọ́ mi kì yóò wúwo sí ọ lára.

“Nítòótọ́ ìwọ sọ ní etí mi,
    èmí sì gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀ wí pé,
‘Èmi mọ́, láìní ìrékọjá, aláìṣẹ̀ ní èmi;
    bẹ́ẹ̀ àìṣedéédéé kò sí ní ọwọ́ mi.
10 Kíyèsi i, Ọlọ́run ti rí àìṣedéédéé pẹ̀lú mi;
    ó kà mí sì ọ̀tá rẹ̀.
11 Ó kan ẹ̀ṣẹ̀ mi sínú àbà;
    o kíyèsi ipa ọ̀nà mi gbogbo.’

12 “Kíyèsi i, nínú èyí ìwọ ṣìnà!
    Èmi ó dá ọ lóhùn pé, Ọlọ́run tóbi jù ènìyàn lọ!
13 Nítorí kí ni ìwọ ṣe ń bá a jà, wí pé,
    òun kò ní sọ ọ̀rọ̀ kan nítorí iṣẹ́ rẹ̀?
14 Nítorí pe Ọlọ́run sọ̀rọ̀ lẹ́ẹ̀kan,
    àní, lẹ́ẹ̀kejì, ṣùgbọ́n ènìyàn kò róye rẹ̀.
15 Nínú àlá, ní ojúran òru,
    nígbà tí orun èjìká bá kùn ènìyàn lọ,
    ní sísùn lórí ibùsùn,
16 Nígbà náà ni ó lè sọ̀rọ̀ ní etí wọn,
    yóò sì dẹ́rùbà wọ́n pẹ̀lú ìbáwí,
17 Kí ó lè fa ènìyàn sẹ́yìn kúrò nínú ètè rẹ̀;
    Kí ó sì pa ìgbéraga mọ́ kúrò lọ́dọ̀ ènìyàn;
18 Ó sì fa ọkàn rẹ̀ padà kúrò nínú isà òkú,
    àti ẹ̀mí rẹ̀ láti ṣègbé lọ́wọ́ idà.

19 “A sì nà án lórí ibùsùn ìrora rẹ̀;
    pẹ̀lúpẹ̀lú a fi ìjà egungun rẹ̀ ti ó dúró pẹ́ nà án,
20 bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀mí rẹ kọ oúnjẹ,
    ọkàn rẹ̀ sì kọ oúnjẹ dídùn.
21 Ẹran-ara rẹ̀ run, títí a kò sì fi lè rí i mọ́
    egungun rẹ̀ tí a kò tí rí sì ta jáde.
22 Àní, ọkàn rẹ̀ sì súnmọ́ isà òkú,
    ẹ̀mí rẹ̀ sì súnmọ́ ọ̀dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ ikú.
23 Bí angẹli kan ba wà lọ́dọ̀ rẹ̀,
    ẹni tí ń ṣe alágbàwí,
    ọ̀kan nínú ẹgbẹ̀rún láti fi ọ̀nà pípé hàn ni,
24 Nígbà náà ni ó ṣe oore-ọ̀fẹ́ fún un ó sì wí pé,
    gbà á kúrò nínú lílọ sínú isà òkú;
    èmi ti rà á padà.
25 Ara rẹ̀ yóò sì di ọ̀tun bí i ti ọmọ kékeré,
    yóò sì tún padà sí ọjọ́ ìgbà èwe rẹ̀;
26 Ó gbàdúrà sọ́dọ̀ Ọlọ́run, òun sì ṣe ojúrere rẹ̀,
    o sì rí ojú rẹ̀ pẹ̀lú ayọ̀,
    òhun o san òdodo rẹ̀ padà fún ènìyàn.
27 Ó wá sọ́dọ̀ ènìyàn ó sì wí pé,
    ‘Èmi ṣẹ̀, kò sì ṣí èyí tí o tọ́, mo sì ti yí èyí tí ó tọ́ po,
    a kò sì san ẹ̀san rẹ̀ fún mi;
28 Ọlọ́run ti gba ọkàn mi kúrò nínú lílọ sínú ihò,
    ẹ̀mí mi yóò wà láti jẹ adùn ìmọ́lẹ̀ ayé.’

29 “Wò ó! Nǹkan wọ̀nyí ni Ọlọ́run
    máa ń ṣe fún ènìyàn nígbà méjì àti nígbà mẹ́ta,
30 Láti mú ọkàn rẹ padà kúrò nínú isà òkú,
    láti fi ìmọ́lẹ̀ alààyè han sí i.

31 “Jobu, kíyèsi i gidigidi kí o sì fetí sí mi;
    pa ẹnu rẹ mọ́, èmi ó sì máa sọ ọ́
32 Bí ìwọ bá sì ní ohun wí, dá mi lóhùn;
    máa sọ, nítorí pé èmi fẹ́ dá ọ láre.
33 Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, gbọ́ tèmi;
    pa ẹnu rẹ mọ́, èmi ó sì kọ́ ọ ní ọgbọ́n.”

Elihu pe Jobu níjà

34 Nígbà náà ni Elihu dáhùn, ó sì wí pé:

“Ẹ̀yin ọlọ́gbọ́n ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi,
    kí ẹ sì fi etí sílẹ̀ sí mi ẹ̀yin tí ẹ ní ìmòye.
Nítorí pé etí a máa dán ọ̀rọ̀ wò,
    bí adùn ẹnu ti ń tọ́ oúnjẹ wò.
Ẹ jẹ́ kí a mọ òye ohun tí o tọ́ fún ara wa;
    ẹ jẹ́ kí a mọ ohun tí ó dára láàrín wa.

“Nítorí pé Jobu wí pé, ‘Aláìlẹ́ṣẹ̀ ni èmi;
    Ọlọ́run sì ti gba ìdájọ́ mi lọ.
Èmi ha purọ́ sí ẹ̀tọ́ mi bí,
    bí mo tilẹ̀ jẹ́ aláìjẹ̀bi,
    ọfà rẹ̀ kò ní àwòtán ọgbẹ́.’
Ọkùnrin wo ni ó dàbí Jobu,
    tí ń mu ẹ̀gàn bí ẹní mú omi?
Tí ń bá àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ kẹ́gbẹ́ tí ó
    sì ń bá àwọn ènìyàn búburú rìn.
Nítorí ó sá ti wí pé, ‘Èrè kan kò sí fún ènìyàn,
    tí yóò fi máa ṣe inú dídùn sí Ọlọ́run.’

10 “Ǹjẹ́ nítorí náà, ẹ fetísílẹ̀ sí mi,
    ẹ fi etí sí mi ẹ̀yin ènìyàn amòye:
Ó di èèwọ̀ fún Ọlọ́run ti ìbá fi hùwà búburú,
    àti fún Olódùmarè, tí yóò fi ṣe àìṣedéédéé!
11 Nítorí pé ó ń sán fún ènìyàn fún gẹ́gẹ́ bi ohun tí a bá ṣe,
    yóò sì mú olúkúlùkù kí ó rí gẹ́gẹ́ bí ipa ọ̀nà rẹ̀.
12 Nítòótọ́ Ọlọ́run kì yóò hùwàkiwà;
    bẹ́ẹ̀ ni Olódùmarè kì yóò yí ìdájọ́ po.
13 Ta ni ó fi ìtọ́jú ayé lé e lọ́wọ́,
    tàbí ta ni ó fi gbogbo ayé lé e lọ́wọ́?
14 Bí ó bá gbé ayé rẹ̀ lé kìkì ara rẹ̀
    tí ó sì gba ọkàn rẹ̀ àti ẹ̀mí rẹ̀ sọ́dọ̀ ara rẹ̀,
15 gbogbo ènìyàn ni yóò parun pọ̀,
    ènìyàn a sì tún padà di erùpẹ̀.

16 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí, bí ìwọ bá ní òye,
    gbọ́ èyí; fetísí ohùn ẹnu mi.
17 Ẹni tí ó kórìíra òtítọ́ ha le ṣe olórí bí?
    Ìwọ ó ha sì dá olóòótọ́ àti ẹni ńlá lẹ́bi?
18 O ha tọ́ láti wí fún ọba pé, ‘ènìyàn búburú ní ìwọ,’
    tàbí fún àwọn ọmọ-aládé pé, ‘ìkà ni ẹ̀yin,’
19 Mélòó mélòó fún ẹni tí kì í ṣe ojúsàájú àwọn ọmọ-aládé
    tàbí tí kò kà ọlọ́rọ̀ sí ju tálákà lọ,
    nítorí pé iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni gbogbo wọn í ṣe?
20 Ní ìṣẹ́jú kan ni wọn ó kú,
    àwọn ènìyàn á sì di yíyọ́ lẹ́nu láàrín ọ̀gànjọ́, wọn a sì kọjá lọ;
    a sì mú àwọn alágbára kúrò láìsí ọwọ́ ènìyàn níbẹ̀.

21 “Nítorí pé ojú rẹ̀ ń bẹ ní ipa ọ̀nà ènìyàn,
    òun sì rí ìrìn rẹ̀ gbogbo.
22 Kò sí ibi òkùnkùn, tàbí òjìji ikú,
    níbi tí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ yóò gbé sápamọ́ sí.
23 Nítorí pé òun kò pẹ́ àti kíyèsi ẹnìkan,
    kí òun kí ó sì mú lọ sínú ìdájọ́ níwájú Ọlọ́run.
24 Òun ó sì fọ́ àwọn alágbára túútúú láìní ìwádìí,
    a sì fi ẹlòmíràn dípò wọn,
25 nítorí pé ó mọ iṣẹ́ wọn,
    ó sì yí wọn po ní òru, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n di ìtẹ̀mọ́lẹ̀.
26 Ó kọlù wọ́n nítorí ìwà búburú wọn
    níbi tí àwọn ẹlòmíràn ti lè rí i,
27 nítorí pé wọ́n padà pẹ̀yìndà sí i,
    wọn kò sì fiyèsí ipa ọ̀nà rẹ̀ gbogbo,
28 kí wọn kí ó sì mú igbe ẹkún àwọn tálákà lọ dé ọ̀dọ̀ rẹ̀,
    òun sì gbọ́ igbe ẹkún aláìní.
29 Ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá dákẹ́ síbẹ̀, ta ni yóò dá lẹ́bi?
    Nígbà tí ó bá pa ojú rẹ̀ mọ́, ta ni yóò lè rí i?
Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe si orílẹ̀-èdè tàbí sí ènìyàn kan ṣoṣo;
30     Kí aláìwà bi Ọlọ́run kí ó má bá à jẹ ọba
    kí wọn kí ó má di ìdẹwò fún ènìyàn.

31 “Nítorí pé ẹnìkan ha lè wí fún Ọlọ́run pé,
    èmi jẹ̀bi, èmi kò sì ní ṣẹ̀ mọ́?
32 Èyí tí èmi kò rí ìwọ fi kọ́ mi
    bi mo bá sì dẹ́ṣẹ̀ èmi kì yóò ṣe bẹ́ẹ̀ mọ́.
33 Ǹjẹ́ bí ti inú rẹ̀ ni ki òun ó san ẹ̀ṣẹ̀ padà?
    Ǹjẹ́ òun yóò san án padà bí ìwọ bá kọ̀ ọ́ láti jẹ́wọ́,
ìwọ gbọdọ̀ yan, kì í ṣe èmi.
    Nítorí náà sọ ohun tí o mọ̀;
    Pẹ̀lúpẹ̀lú ohun tí ìwọ mọ̀, sọ ọ́!

34 “Àwọn ènìyàn amòye yóò wí fún mi,
    àti pẹ̀lúpẹ̀lú ẹnikẹ́ni tí í ṣe ọlọ́gbọ́n tí ó sì gbọ́ mi pé,
35 ‘Jobu ti fi àìmọ̀ sọ̀rọ̀,
    ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì ṣe aláìgbọ́n.’
36 Ìfẹ́ mi ni kí a dán Jobu wò dé òpin,
    nítorí ìdáhùn rẹ̀ dàbí i ti ènìyàn búburú:
37 Nítorí pe ó fi ìṣọ̀tẹ̀ kún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀;
    ó pàtẹ́wọ́ ní àárín wa,
    ó sì sọ ọ̀rọ̀ odi púpọ̀ sí Ọlọ́run.”

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)

Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.