Print Page Options
Previous Prev Day Next DayNext

Beginning

Read the Bible from start to finish, from Genesis to Revelation.
Duration: 365 days
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Version
Habakuku 1-3

Àsọtẹ́lẹ̀ tí wòlíì Habakuku rí.

Ìráhùn Habakuku

(A)Olúwa, èmi yóò ti ké pẹ́ tó fún ìrànlọ́wọ́,
    Ṣùgbọ́n ti ìwọ kò ni fetí sí mi?
Tàbí kígbe sí ọ ní ti, “Ìwà ipá!”
    ṣùgbọ́n tí ìwọ kò sì gbàlà?
Èéṣe tí ìwọ fi mú mi rí àìṣedéédéé
    Èéṣe tí ìwọ sì fi ààyè gba ìwà ìkà?
Ìparun àti ìwà ipá wà ní iwájú mi;
    ìjà ń bẹ, ìkọlù sì wà pẹ̀lú.
Nítorí náà, òfin di ohun àìkàsí,
    ìdájọ́ òdodo kò sì borí.
Àwọn ẹni búburú yí àwọn olódodo ká,
    Nítorí náà ni ìdájọ́ òdodo ṣe yí padà.

Ìdáhùn Olúwa

(B)“Ẹ wo inú àwọn kèfèrí, ki ẹ sí wòye,
    Kí háà kí ó sì ṣe yin gidigidi.
Nítorí èmi ó ṣe ohun kan ní ọjọ́ yín
    tí ẹ̀yin kò jẹ́ gbàgbọ́,
    bí a tilẹ̀ sọ fún yin.
(C)Nítorí pé, èmi yóò gbé àwọn ara Babeli dìde,
    àwọn aláìláàánú àti onínú-fùfù ènìyàn
tí ó rin gbogbo ilẹ̀ ayé já
    láti fi agbára gbà àwọn ibùgbé tí kì í ṣe tiwọn.
Wọn jẹ́ ènìyàn ti a bẹ̀rù, tí a sì páyà,
    ìdájọ́ wọn, àti ọláńlá wọn,
    Yóò máa ti inú wọn jáde.
Ẹṣin wọn yára ju ẹkùn lọ,
    wọ́n sì gbóná jú ìkookò àṣálẹ́ lọ
àwọn ẹlẹ́ṣin wọn yóò sí tan ara wọn ká;
    wọn yóò sì wá láti ọ̀nà jíjìn réré,
wọn yóò sí fò bí ẹyẹ igún tí ń wá láti jẹrun
    Gbogbo wọn sì wà fún ìwà ipá
ìwò ojú wọn yóò sì wá síwájú;
    wọn sì ko ìgbèkùn jọ bí iyanrìn.
10 Wọn ó si máa fi àwọn ọba ṣẹ̀sín
    wọn ó sì tún kẹ́gàn àwọn aládé.
Wọn yóò sì fi gbogbo ìlú odi alágbára nì rẹ́rìn-ín;
    Nítorí pé, wọn yóò ko erùpẹ̀ jọ, wọn yóò sì gbà á
11 Nígbà náà ni inú rẹ̀ yóò yípadà,
    yóò sì rékọjá, yóò si ṣẹ̀ ní kíka agbára rẹ̀ yìí sí iṣẹ́ òrìṣà rẹ̀.”

Ìráhùn lẹ́ẹ̀kejì Habakuku

12 Olúwa, ǹjẹ́ láti ayérayé kọ ni ìwọ tí wà?
    Olúwa Ọlọ́run mi. Ẹni mímọ́ mi, àwa kì yóò kú
Olúwa, ìwọ tí yàn wọn fún ìdájọ́;
    Ọlọ́run alágbára, ìwọ tí fi ẹsẹ̀ wọn múlẹ̀ fún ìbáwí
13 Ojú rẹ mọ́ tónítóní láti wo ibi;
    ìwọ kò le gbà ìwà ìkà
nítorí kí ni ìwọ ṣe gba àwọn alárékérekè láààyè?
    Nítorí kí ni ìwọ ṣe dákẹ́ nígbà tí ẹni búburú ń pa
    ẹni tí i ṣe olódodo ju wọn lọ run?
14 Ìwọ sì tí sọ ènìyàn di bí ẹja inú Òkun,
    bí ohun tí ń rákò tí wọn ko ni alákòóso
15 Àwọn ènìyàn búburú fi àwọ̀n wọn gbé wọn sókè
    ó sì kó wọn jọ nínú àwọ̀n ńlá rẹ̀;
    nítorí náà, ó dunnú, ó sì yọ̀ pẹ̀lú.
16 Nítorí náà, ó rú ẹbọ sí àwọ̀n rẹ̀,
    ó sì ń sun tùràrí fún àwọ̀n ńlá rẹ̀
nítorí pẹ̀lú àwọ̀n rẹ̀ ni ó fi ń gbé ní ìgbádùn
    tí ó sì ń gbádùn pẹ̀lú oúnjẹ tí ó bá wù ú.
17 Ǹjẹ́ wọn yóò ha máa pa àwọ̀n wọn mọ́ ní òfìfo bí,
    tí wọn yóò sì pa orílẹ̀-èdè run láìsí àánú?

Ìdáhùn Ọlọ́run sí ìráhùn wòlíì Habakuku

(D)Èmi yóò dúró lórí ibusọ́ mi láti máa wòye
    Èmi yóò sì gbé ara mi ka orí alóre
Èmi yóò si ṣọ́ láti gbọ́ ohun tí yóò sọ fún mi
    àti èsì ti èmi yóò fún ẹ̀sùn yìí nígbà tó bá ń bá mi wí.

Ìdáhùn Olúwa

Nígbà náà ni Olúwa dáhùn pé:

“Kọ ìṣípayá náà sílẹ̀
    kí o sì fi hàn ketekete lórí wàláà
    kí ẹni tí ń kà á, lè máa sáré.
(E)Nítorí ìṣípayá náà jẹ́ tí ìgbà kan tí a múra sílẹ̀ dè;
    yóò máa yára sí ìgbẹ̀yìn
    kí yóò sìsọ èké.
Bí o tilẹ̀ lọ́ra, dúró dè é;
    nítorí, dájúdájú, yóò dé, kí yóò sí pẹ́.”

(F)“Kíyèsi, ọkàn rẹ tí ó gbéga;
    Ìfẹ́ rẹ̀ kò dúró ṣinṣin nínú rẹ̀,
    ṣùgbọ́n olódodo yóò wa nípa ìgbàgbọ́ rẹ̀.
Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lú, nítorí tí ọtí wáìnì ni ẹ̀tàn,
    agbéraga ènìyàn òun, kò sì ní sinmi
ẹni tí ó sọ ìwọra rẹ di gbígbòòrò bí isà òkú,
    ó sì dàbí ikú, a kò sì le tẹ́ ẹ lọ́rùn,
ó kó gbogbo orílẹ̀-èdè jọ sí ọ̀dọ̀
    ó sì gba gbogbo ènìyàn jọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀.

“Gbogbo àwọn wọ̀nyí kì yóò máa pa òwe sí i tí wọn yóò sì máa kọ orin òwe sí i wí pé,

“ ‘Ègbé ni fún ẹni tí ń mu ohun tí kì í ṣe tirẹ̀ pọ̀ sí i!
    Tí ó sì sọ ara rẹ̀ di ọlọ́rọ̀ nípasẹ̀ ìlọ́nilọ́wọ́gbà!
    Eléyìí yóò ha ti pẹ́ tó?’
Ǹjẹ́ ẹni ti ó yọ ọ́ lẹ́nu, kí yóò ha dìde ní òjijì?
    Àti àwọn tí ó wàhálà rẹ kì yóò jí, kí wọn ó sì dẹ́rùbà ọ́?
    Nígbà náà ni ìwọ yóò wa dí ìkógun fún wọn.
Nítorí ìwọ ti kó orílẹ̀-èdè púpọ̀,
    àwọn ènìyàn tókù yóò sì kó ọ
nítorí ìwọ tí ta ẹ̀jẹ̀ ènìyàn sílẹ̀; nítorí ẹ̀jẹ̀
    Ìwọ tí pa ilẹ̀ àti ìlú ńlá run
    àti gbogbo ènìyàn to ń gbé inú rẹ̀.

“Ègbé ni fún ẹni tí ń jẹ èrè ìjẹkújẹ sí ilé rẹ̀,
    tí o sí gbé ìtẹ́ rẹ̀ lórí ibi gíga,
    kí a ba le gbà á sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ibi!
10 Ìwọ ti gbìmọ̀ ìtìjú sí ilé rẹ
    nípa kíké ènìyàn púpọ̀ kúrò;
    ìwọ sì ti pàdánù ẹ̀mí rẹ
11 Nítorí tí òkúta yóò kígbe jáde láti inú ògiri wá,
    àti ìtí igi láti inú igi rírẹ́ wá yóò sì dá a lóhùn.

12 “Ègbé ni fún ẹni tí ó fi ẹ̀jẹ̀ kọ́ ìlú,
    tí o sì fi àìṣedéédéé tẹ ìlú ńlá dó?
13 Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun kò ha ti ṣètò rẹ̀ pé
    làálàá àwọn ènìyàn jẹ́ epo fún iná
    kí àwọn orílẹ̀-èdè náà sì máa ṣe wàhálà fún asán?
14 Nítorí tí ayé yóò kún fún ìmọ̀ ògo Olúwa,
    bí omi ti bo Òkun.

15 “Ègbé ni fún ẹni tí ó fi ohun mímu fún aládùúgbò rẹ̀,
    tí ó sì fi ọtí-lílé rẹ̀ fún un, tí o sì jẹ́ kó mu àmupara,
    kí ìwọ kí ó ba lè wo ìhòhò wọn”
16 Ìtìjú yóò bò ọ́ dípò ògo, ìwọ náà mu pẹ̀lú
    kí ìhòhò rẹ kí ó lè hàn,
ago ọwọ́ ọ̀tún Olúwa, yóò yípadà sí ọ,
    ìtìjú yóò sì bo ògo rẹ.
17 Nítorí ìwà ipá tí ó tí hù sí Lebanoni yóò bò ọ́,
    àti ìparun àwọn ẹranko yóò dẹ́rùbà ọ́ mọ́lẹ̀
Nítorí ìwọ tí ta ẹ̀jẹ̀ ènìyàn sílẹ̀;
    ìwọ tí pa ilẹ̀ náà àti ìlú ńlá run àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.

18 “Èrè kí ni òrìṣà ni, tí oníṣọ̀nà rẹ̀ fi gbẹ́ ẹ,
    ère dídá ti ń kọ ni èké?
Nítorí ti ẹni ti ó dá a gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé ohun tí ó fúnrarẹ̀ dá;
    ó sì mọ ère tí kò le fọhùn.
19 Ègbé ni fún ẹni ti ń sọ fún igi pé, ‘di alààyè?’
    Fún òkúta tí kò lè fọhùn pé, ‘Dìde’
Ǹjẹ́ òun lè tọ́ ni sí ọ̀nà?
    Wúrà àti fàdákà ni a fi bò ó yíká;
    kò sì sí èémí kan nínú rẹ.”

20 (G)Ṣùgbọ́n Olúwa wà nínú tẹmpili mímọ́ rẹ̀;
    Ẹ jẹ́ kí gbogbo ayé parọ́rọ́ níwájú rẹ.

Àdúrà Habakuku

Àdúrà wòlíì Habakuku gẹ́gẹ́ bí sígónótì. Ohun èlò orin.

Olúwa mo tí gbọ́ ohùn rẹ;
    ẹ̀rù sì ba mi fún iṣẹ́ rẹ Olúwa
sọ wọn di ọ̀tún ní ọjọ́ ti wa,
    ní àkókò tiwa, jẹ́ kó di mí mọ̀;
    ni ìbínú, rántí àánú.

Ọlọ́run yóò wa láti Temani,
    ibi mímọ́ jùlọ láti Òkè Parani
ògo rẹ̀ sí bo àwọn ọ̀run,
    ilé ayé sì kún fún ìyìn rẹ
Dídán rẹ sí dàbí ìmọ́lẹ̀ oòrùn
    ìtànṣán ìmọ́lẹ̀ jáde wa láti ọwọ́ rẹ,
    níbi tí wọn fi agbára rẹ̀ pamọ́ sí.
Àjàkálẹ̀-ààrùn ń lọ ni iwájú rẹ;
    ìyọnu sí ń tọ ẹsẹ̀ rẹ lọ.
Ó dúró, ó sì mi ayé;
    ó wò, ó sì mú àwọn orílẹ̀-èdè wárìrì
a sì tú àwọn òkè ńlá ayérayé ká,
    àwọn òkè kéékèèkéé ayérayé sì tẹríba:
    ọ̀nà rẹ ayérayé ni.
Mo rí àgọ́ Kuṣani nínú ìpọ́njú
    àti àwọn ibùgbé Midiani nínú ìrora.

Ǹjẹ́ ìwọ ha ń bínú sí àwọn Odò nì, Olúwa?
    Ǹjẹ́ ìbínú rẹ wa lórí àwọn odò ṣíṣàn bí?
Ìbínú rẹ ha wá sórí Òkun
    tí ìwọ fi ń gun ẹṣin,
    àti kẹ̀kẹ́ ìgbàlà rẹ?
A ṣí ọrun rẹ sílẹ̀ pátápátá,
    gẹ́gẹ́ bí ìbúra àwọn ẹ̀yà, àní ọ̀rọ̀ rẹ,
ìwọ sì fi odò pín ilẹ̀ ayé.
10     Àwọn òkè ńlá ri ọ wọn sì wárìrì
àgbàrá òjò ń sàn án kọjá lọ;
    ibú ń ké ramúramù
    ó sì gbé irú omi sókè.

11 Òòrùn àti Òṣùpá dúró jẹ́ẹ́jẹ́ ni ibùgbé wọn,
    pẹ̀lú ìmọ́lẹ̀ ọfà rẹ ni wọn yára lọ,
    àti ni dídán ọ̀kọ̀ rẹ ti ń kọ mànà.
12 Ní ìrunú ni ìwọ rin ilẹ̀ náà já,
    ní ìbínú ni ìwọ tí tẹ́ àwọn orílẹ̀-èdè rẹ.
13 Ìwọ jáde lọ láti tú àwọn ènìyàn rẹ sílẹ̀,
    àti láti gba ẹni ààmì òróró rẹ là;
Ìwọ ti run àwọn olórí kúrò nínú ilẹ̀ àwọn ènìyàn búburú,
    ó sì bọ ìhámọ́ra rẹ láti orí de ẹsẹ̀
14 Pẹ̀lú ọ̀kọ̀ rẹ̀ kí ó fi gún orí rẹ
    nígbà tí àwọn jagunjagun rẹ̀
jáde láti tú wá ká:
    ayọ̀ wọn sì ni láti jẹ tálákà run ní ìkọ̀kọ̀.
15 Ìwọ fi ẹṣin rẹ rìn Òkun já,
    ó sì da àwọn omi ńlá ru.

16 Mo gbọ́, ọkàn mi sì wárìrì,
    ètè mi sì gbọ̀n sí ìró náà;
ìbàjẹ́ sì wọ inú egungun mi lọ,
    ẹsẹ̀ mi sì wárìrì,
mo dúró ni ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ fún ọjọ́ ìdààmú
    láti de sórí àwọn ènìyàn tó ń dojúkọ wá.
17 Bí igi ọ̀pọ̀tọ́ ko tilẹ̀ tanná,
    tí èso kò sí nínú àjàrà;
tí igi olifi ko le so,
    àwọn oko ko sì mú oúnjẹ wá;
tí a sì ké agbo ẹran kúrò nínú agbo,
    tí kò sì sí ọwọ́ ẹran ni ibùso mọ́,
18 síbẹ̀, èmi ó láyọ̀ nínú Olúwa,
    èmi yóò sí máa yọ nínú Ọlọ́run ìgbàlà mi.

19 Olúwa Olódùmarè ni agbára mi,
    òun yóò sí ṣe ẹsẹ̀ mi bí ẹsẹ̀ abo àgbọ̀nrín,
    yóò sí mú mi rìn lórí ibi gíga.

Sí olórí akọrin lórí ohun èlò orin olókùn mi.

Sefaniah 1-3

Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Sefaniah ọmọ Kuṣi, ọmọ Gedaliah, ọmọ Amariah, ọmọ Hesekiah, ní ìgbà Josiah ọmọ Amoni ọba Juda.

Ìkìlọ̀ fún ìparun tí ń bọ̀

“Èmi yóò mú gbogbo nǹkan kúrò
    lórí ilẹ̀ náà pátápátá,”
    ni Olúwa wí.
“Èmi yóò mú ènìyàn àti ẹranko
    kúrò; èmi yóò mú àwọn ẹyẹ ojú
    ọ̀run kúrò àti ẹja inú Òkun, àti
ohun ìdìgbòlù pẹ̀lú àwọn
    ènìyàn búburú; èmi yóò ké ènìyàn kúrò lórí ilẹ̀ ayé,”
    ni Olúwa wí.

Ìlòdì sí Juda

“Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Juda
    àti sórí gbogbo àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Jerusalẹmu.
Èmi yóò sì ké kúrò níhìn-ín-yìí ìyókù àwọn Baali, àti orúkọ àwọn abọ̀rìṣà
    pẹ̀lú àwọn àlùfáà abọ̀rìṣà,
àti àwọn tí ń foríbalẹ̀ lórí òrùlé,
    àwọn tí ń sin ogun ọ̀run,
àwọn tó ń foríbalẹ̀, tí wọ́n sì ń fi Olúwa búra,
    tí wọ́n sì ń fi Moleki búra.
Àwọn tí ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ Olúwa;
    Àti àwọn tí kò tí wá Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì béèrè rẹ̀.”

(A)Ẹ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú Olúwa Olódùmarè,
    nítorí tí ọjọ́ Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀.
Olúwa ti pèsè ẹbọ kan sílẹ̀,
    ó sì ti ya àwọn alápèjẹ rẹ̀ sí mímọ́.

“Ní ọjọ́ ẹbọ Olúwa,
    Èmi yóò bẹ àwọn olórí wò, àti àwọn
    ọmọ ọba ọkùnrin,
pẹ̀lú gbogbo
    àwọn tí ó wọ àjèjì aṣọ.
Ní ọjọ́ náà, èmi yóò fi ìyà jẹ
    gbogbo àwọn tí ó yẹra láti rìn lórí ìloro ẹnu-ọ̀nà,
tí wọ́n sì kún tẹmpili àwọn ọlọ́run wọn
    pẹ̀lú ìwà ipá àti ẹ̀tàn.

10 “Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí,
    “Ohùn ẹkún yóò wà láti ìhà Ibodè ẹja,
    híhu láti ìhà kejì wá àti
    ariwo ńlá láti òkè kékeré wá.
11 Ẹ hu, ẹ̀yin tí ń gbé ní (Maktẹsi) agbègbè ọjà,
    gbogbo àwọn oníṣòwò rẹ̀ ni a ó mú kúrò,
    gbogbo àwọn ẹni tí ó ń ra fàdákà ni a ó sì parun.
12 Ní àkókò wọ̀n-ọn-nì, èmi yóò wá Jerusalẹmu kiri pẹ̀lú fìtílà,
    èmi ó sì fi ìyà jẹ àwọn tí kò ní ìtẹ́lọ́rùn,
    tí wọn sì dàbí àwọn ènìyàn tí ó sinmi sínú gẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀ wọn,
àwọn tí wọn sì ń wí ní ọkàn wọn pé, ‘Olúwa kì yóò ṣe nǹkan kan
    tí ó jẹ́ rere tàbí tí ó jẹ́ búburú.’
13 Nítorí náà, ọrọ̀ wọn yóò di ìkógun,
    àti ilé wọn yóò sì run.
Àwọn yóò sì kọ́ ilé pẹ̀lú, ṣùgbọ́n
    wọn kì yóò gbé nínú ilé náà,
wọn yóò gbin ọgbà àjàrà,
    ṣùgbọ́n wọn kì yóò mu ọtí
wáìnì láti inú rẹ̀.”

Ọjọ́ ńlá Olúwa

14 “Ọjọ́ ńlá Olúwa kù sí dẹ̀dẹ̀,
    ó kù sí dẹ̀dẹ̀ ó sì ń yára bọ̀
kánkán. Ẹ tẹ́tí sílẹ̀, ohùn ẹkún
    àwọn alágbára ní ọjọ́ Olúwa yóò korò púpọ̀,
15 Ọjọ́ náà yóò jẹ́ ọjọ́ ìbínú,
    ọjọ́ ìrora àti ìpọ́njú,
ọjọ́ òfò àti idà ọjọ́ ìdahoro
    ọjọ́ òkùnkùn àti ìtẹ̀ba,
    ọjọ́ kurukuru àti òkùnkùn biribiri,
16 ọjọ́ ìpè àti ìpè ogun
    sí àwọn ìlú olódi
    àti sí àwọn ilé ìṣọ́ gíga.

17 “Èmi yóò sì mú ìpọ́njú wá sórí
    ènìyàn, wọn yóò sì máa rìn gẹ́gẹ́ bí afọ́jú,
    nítorí àwọn ti dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa.
Ẹ̀jẹ̀ wọn ni a ó sì tú jáde bí eruku
    àti ẹran-ara wọn bí ìgbẹ́.
18 Bẹ́ẹ̀ ni fàdákà tàbí wúrà wọn
    kì yóò sì le gbà wọ́n là
    ní ọjọ́ ìbínú Olúwa.”

Ṣùgbọ́n gbogbo ayé ni a ó fi iná
    ìjowú rẹ̀ parun,
nítorí òun yóò fi ìyára fi òpin sí
    gbogbo àwọn tí ń gbé ní ilẹ̀ ayé.

Ìpè si Ìrònúpìwàdà

Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, àní ẹ kó ra yín jọ pọ̀
    orílẹ̀-èdè tí kò ní ìtìjú,
kí a tó pa àṣẹ náà, kí ọjọ́ náà tó kọjá bí ìyàngbò ọkà,
    kí gbígbóná ìbínú Olúwa tó dé bá a yín,
kí ọjọ́ ìbínú Olúwa kí ó tó dé bá a yín.
Ẹ wá Olúwa, gbogbo ẹ̀yin onírẹ̀lẹ̀ ilẹ̀ náà,
    ẹ̀yin tí ń ṣe ohun tí ó bá pàṣẹ.
Ẹ wá òdodo, ẹ wá ìrẹ̀lẹ̀ pẹ̀lú,
    bóyá á ó pa yín mọ́ ní ọjọ́ ìbínú Olúwa.

Ìlòdì sí Filistia

(B)Nítorí pé, a ó kọ Gasa sílẹ̀,
    Aṣkeloni yóò sì dahoro.
Ní ọ̀sán gangan ni a ó lé Aṣdodu jáde,
    a ó sì fa Ekroni tu kúrò.
Ègbé ni fún ẹ̀yin tí ń gbé etí Òkun,
    ẹ̀yin ènìyàn ara Kereti;
Ọ̀rọ̀ Olúwa dojúkọ ọ́, ìwọ Kenaani,
    ilẹ̀ àwọn ara Filistini.
“Èmi yóò pa yín run,
    ẹnìkan kò sì ní ṣẹ́kù nínú yín.”
Ilẹ̀ náà ní etí Òkun, ni ibùgbé àwọn ará Kereti,
    ni yóò jẹ́ ibùjókòó fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn àti agbo àgùntàn.
Agbègbè náà yóò sì jẹ́ ti ìyókù àwọn ilé Juda,
    níbẹ̀ ni wọn yóò sì ti rí koríko fún ẹran,
Ní ilé Aṣkeloni ni wọn yóò
    dùbúlẹ̀ ni àṣálẹ́.
Olúwa Ọlọ́run wọn yóò bẹ̀ wọn wò,
    yóò sì yí ìgbèkùn wọn padà.

Ìlòdì sí Moabu àti Ammoni

(C)“Èmi ti gbọ́ ẹ̀gàn Moabu,
    àti ẹlẹ́yà àwọn Ammoni,
àwọn tó kẹ́gàn àwọn ènìyàn mi,
    tí wọ́n sì ti gbé ara wọn ga sí agbègbè wọn.
Nítorí náà, bí Èmi tí wà,”
    ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn Israẹli wí,
    “nítòótọ́ Moabu yóò dàbí Sodomu
àti Ammoni yóò sì dàbí Gomorra,
    ibi tí ó kún fún yèrèpè
àti ìhó iyọ̀ àti ìdahoro títí láéláé.
    Ìyókù àwọn ènìyàn mi yóò kó wọn;
àwọn tí ó sì yọ nínú ewu ní orílẹ̀-èdè mi ni
    yóò jogún ilẹ̀ wọn.”

10 Èyí ni ohun tí wọn yóò gbà padà nítorí ìgbéraga wọn,
    nítorí wọ́n kẹ́gàn, wọn sì ti fi àwọn ènìyàn Olúwa àwọn ọmọ-ogun ṣe ẹlẹ́yà.
11 Olúwa yóò jẹ́ ìbẹ̀rù fún wọn;
    nígbà tí Òun bá pa gbogbo òrìṣà ilẹ̀ náà run.
Orílẹ̀-èdè láti etí odò yóò máa sìn,
    olúkúlùkù láti ilẹ̀ rẹ̀ wá.
12 “Ẹ̀yin Etiopia pẹ̀lú,
    a ó fi idà mi pa yín.”

Asiria

13 Òun yóò sì na ọwọ́ rẹ̀ sí apá àríwá,
    yóò sì pa Asiria run,
yóò sì sọ Ninefe di ahoro,
    àti di gbígbẹ bí aginjù.
14 Agbo ẹran yóò sì dùbúlẹ̀ ni àárín rẹ̀,
    àti gbogbo ẹranko àwọn orílẹ̀-èdè.
Òwìwí aginjù àti ti n kígbe ẹyẹ òwìwí
    yóò wọ bí ẹyẹ ni ọwọ́n rẹ̀.
Ohùn wọn yóò kọrin ni ojú fèrèsé,
    ìdahoro yóò wà nínú ìloro ẹnu-ọ̀nà,
    òun yóò sì ṣẹ́ ọ̀pá kedari sílẹ̀.
15 Èyí ni ìlú aláyọ̀ tí ó ń gbé láìléwu.
    Ó sì sọ fun ara rẹ̀ pé,
“Èmi ni, kò sì sí ẹnìkan tí ó ń bẹ lẹ́yìn mi.”
    Irú ahoro wo ni òun ha ti jẹ́,
ibùgbé fún àwọn ẹranko igbó!
    Gbogbo ẹni tí ó bá kọjá ọ̀dọ̀ rẹ̀
yóò fi rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà,
    wọ́n yóò sì gbọn ẹsẹ̀ wọn.

Ọjọ́ iwájú Jerusalẹmu

Ègbé ni fún ìlú aninilára,
    ọlọ̀tẹ̀ àti aláìmọ́.
Òun kò gbọ́rọ̀ sí ẹnikẹ́ni,
    òun kò gba ìtọ́ni,
òun kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa,
    bẹ́ẹ̀ ni òun kò súnmọ́ ọ̀dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀.
Àwọn olórí rẹ̀ jẹ́ kìnnìún tí ń ké ramúramù,
    àwọn onídàájọ́ rẹ̀, ìkookò àṣálẹ́ ni wọn,
    wọn kò sì fi nǹkan kan kalẹ̀ fún òwúrọ̀.
Àwọn wòlíì rẹ̀ gbéraga,
    wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ènìyàn.
Àwọn àlùfáà rẹ̀ ti ba ibi mímọ́ jẹ́,
    wọ́n sì rú òfin.
Olúwa ni àárín rẹ̀ jẹ́ olódodo;
    kì yóò ṣe ohun tí kò tọ̀nà.
Àràárọ̀ ni ó máa ń mú ìdájọ́ rẹ̀ wá sí ìmọ́lẹ̀,
    kì í sì kùnà ní gbogbo ọjọ́ tuntun,
    síbẹ̀ àwọn aláìṣòótọ́ kò mọ ìtìjú.
“Èmi ti ké àwọn orílẹ̀-èdè kúrò,
    ilé gíga wọn sì ti bàjẹ́.
Mo ti fi ìgboro wọn sílẹ̀ ní òfo
    tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnìkankan kò kọjá níbẹ̀.
Ìlú wọn parun tó bẹ́ẹ̀ tí kò sí
    ẹnìkan tí yóò ṣẹ́kù,
    kò sì ní sí ẹnìkan rárá.
Èmi wí fún ìlú náà wí pé
    ‘Nítòótọ́, ìwọ yóò bẹ̀rù mi,
    ìwọ yóò sì gba ìtọ́ni!’
Bẹ́ẹ̀ ni, a kì yóò ké ibùgbé rẹ̀ kúrò
    bí ó ti wù kí ń jẹ wọ́n ní yà tó.
Ṣùgbọ́n síbẹ̀ wọ́n sì tún ní ìtara
    láti ṣe ìbàjẹ́.
Nítorí náà ẹ dúró dè mí,” ni Olúwa wí,
    “títí di ọjọ́ náà tí èmi yóò fi jẹ́rìí sí yin;
nítorí ìpinnu mi ni láti kó orílẹ̀-èdè jọ
    kí èmi kí ó lè kó ilẹ̀ ọba jọ
àti láti da ìbínú mi jáde sórí wọn,
    àní gbogbo ìbínú gbígbóná mi.
Nítorí, gbogbo ayé
    ni a ó fi iná owú mi jẹ run.

“Nígbà náà ni èmi yóò yí èdè àwọn ènìyàn padà sí èdè mímọ́,
    nítorí kí gbogbo wọn bá a lè máa pe orúkọ Olúwa,
    láti fi ọkàn kan sìn ín.
10 Láti òkè odò Etiopia,
    àwọn olùjọsìn mi, àwọn ènìyàn mi tí ó ti fọ́nká,
    yóò mú ọrẹ wá fún mi.
11 Ní ọjọ́ náà ni a kì yóò sì dójútì
    nítorí gbogbo iṣẹ́ ibi ni tí ó ti ṣẹ̀ sí mi,
nígbà náà ni èmi yóò mu
    kúrò nínú ìlú yìí, àwọn tí ń yọ̀ nínú ìgbéraga wọn.
Ìwọ kì yóò sì gbéraga mọ́
    ní òkè mímọ́ mi.
12 Ṣùgbọ́n Èmi yóò fi àwọn ọlọ́kàn tútù
    àti onírẹ̀lẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú ni àárín rẹ̀,
    wọn yóò sì gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa.
13 Àwọn ìyókù Israẹli kì yóò hùwà
    ibi, wọn kì yóò sọ̀rọ̀ èké,
    bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò rí ahọ́n àrékérekè ní
ẹnu wọn. Àwọn yóò jẹun, wọn yóò sì dùbúlẹ̀,
    bẹ́ẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kì yóò dẹ́rùbà wọ́n.”

14 Kọrin, ìwọ ọmọbìnrin Sioni,
    kígbe sókè, ìwọ Israẹli!
Fi gbogbo ọkàn yọ̀, kí inú rẹ kí ó sì dùn,
    ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu.
15 Olúwa ti mú ìdájọ́ rẹ wọ̀n-ọn-nì
    kúrò, ó sì ti ti àwọn ọ̀tá rẹ padà sẹ́yìn.
Olúwa, ọba Israẹli wà pẹ̀lú rẹ,
    Ìwọ kì yóò sì bẹ̀rù ibi kan mọ́.
16 Ní ọjọ́ náà, wọn yóò sọ fún Jerusalẹmu pé,
    “Má ṣe bẹ̀rù Sioni;
    má sì ṣe jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó dẹ̀.
17 Olúwa Ọlọ́run rẹ wà pẹ̀lú rẹ,
    Ó ní agbára láti gbà ọ là.
Yóò yọ̀ ni orí rẹ fún ayọ̀;
    Yóò tún ọ ṣe nínú ìfẹ́ rẹ̀,
    Yóò sì fi orin yọ̀ ní orí rẹ.”

18 “Èmi ó kó àwọn tí ó ń banújẹ́ fún àjọ̀dún tí a yàn jọ,
    àwọn tí ó jẹ́ tirẹ̀;
    àwọn tí ẹ̀gàn rẹ̀ jásí ẹ̀rù.
19 Ní àkókò náà
    ni èmi yóò dojúkọ àwọn
tí ń ni yín lára,
    èmi yóò gba àtiro là,
èmi yóò sì ṣa àwọn tí ó ti fọ́nká jọ,
    èmi yóò fi ìyìn àti ọlá fún wọn ní
    gbogbo ilẹ̀ tí a bá ti dójútì wọ́n.
20 Ní àkókò náà ni èmi yóò ṣà yín jọ;
    Nígbà náà ni èmi yóò mú un yín padà wá sílé.
Èmi yóò fi ọlá àti ìyìn fún un yín
    láàrín gbogbo ènìyàn àgbáyé,
nígbà tí èmi yóò yí ìgbèkùn yín
    padà bọ sípò ní ojú ara yín,”
    ni Olúwa wí.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)

Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.