Eksodu 25
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn
Ọrẹ ẹbọ fún àgọ́
25 (A)Olúwa sì wí fún Mose pé, 2 (B)“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli kí wọn mú ọrẹ wá fún mi, ìwọ yóò gba ọrẹ náà fún mi ni ọwọ́ ọkùnrin kọ̀ọ̀kan ti ọkàn rẹ bá fẹ́ láti fi fún mi.
3 “Wọ̀nyí ni ọrẹ ti ìwọ yóò gbà ni ọwọ́ wọn:
“wúrà, fàdákà àti idẹ;
4 aṣọ aláró, elése àlùkò, òdòdó, ọ̀gbọ̀;
irun ewúrẹ́.
5 Awọ àgbò tí a rẹ ní pupa àti awọ ewúrẹ́ igbó;
igi kasia;
6 Òróró olifi fún iná títàn;
òróró olóòórùn dídùn fún ìtasórí àti fún tùràrí olóòórùn dídùn;
7 àti òkúta óníkìsì àti òkúta olówó iyebíye ti a fi ṣe ọ̀ṣọ́ sí ara ẹ̀wù efodu àti ẹ̀wù ìgbàyà.
8 “Nígbà náà ni ìwọ yóò jẹ́ kí wọn kọ́ ibi mímọ́ fún mi. Èmi yóò sì máa gbé ní àárín wọn. 9 Gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí ti mo fihàn ọ́, nípa àpẹẹrẹ àgọ́, àti àpẹẹrẹ gbogbo ohun èlò inú rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ̀yin kí ó sì ṣe é.
Àpótí ẹ̀rí
10 (C)“Wọn yóò sì fi igi ṣittimu ṣe àpótí, ìgbọ̀nwọ́ méjì ààbọ̀ ni gígùn rẹ̀, ìgbọ̀nwọ́ kan ààbọ̀ ni fífẹ̀ rẹ̀, ìgbọ̀nwọ́ kan ààbọ̀ ni gíga rẹ̀. 11 Ìwọ ó sì fi ojúlówó wúrà, bò ó ní inú àti ní òde, ìwọ ó sì fi wúrà gbá etí rẹ̀ yíká. 12 Ìwọ ó sì da òrùka wúrà mẹ́rin fún. Ìwọ ó sì fi wọ́n sí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ẹsẹ̀ rẹ̀, òrùka wúrà méjì yóò wà ní ẹ̀gbẹ́ kìn-ín-ní, òrùka wúrà méjì yóò wà ní ẹgbẹ́ kejì. 13 Ìwọ ó sì fi igi kasia ṣe ọ̀pá mẹ́rin, ìwọ ó sì fi wúrà bò wọ́n. 14 ìwọ ó sì fi ọ̀pá náà bọ òrùka ní ẹ̀gbẹ́ kọ̀ọ̀kan àpótí ẹ̀rí náà láti fi gbé e. 15 Òpó náà yóò wá nínú òrùka lára àpótí ẹ̀rí; a kò ní yọ wọ́n kúrò. 16 Nígbà náà ni ìwọ yóò fi ẹ̀rí ti èmi yóò fi fún ọ sínú àpótí náà.
17 “Ìwọ ó sì fi ojúlówó wúrà ṣe ìtẹ́ àánú; ìgbọ̀nwọ́ méjì àti ààbọ̀ ní gígùn àti ìgbọ̀nwọ́ kan àti ààbọ̀ ní fífẹ̀. 18 Ìwọ ó sì ṣe kérúbù méjì láti inú wúrà tí a fi òòlù sí igun ìtẹ́ àánú náà. 19 Ìwọ ó ṣe kérúbù kan sí igun kìn-ín-ní àti kérúbù kejì sí igun kejì, kí kérúbù náà jẹ́ irú kan náà ní igun méjèèjì pẹ̀lú ìbòrí wọn. 20 Àwọn kérúbù sì na ìyẹ́ apá wọn sókè, tí wọn yóò sì fi ìyẹ́ apá wọn ṣe ibòòji sí orí ìtẹ́ àánú. Àwọn kérúbù náà yóò kọ ojú sí ara wọn, wọn yóò máa wo ọ̀kánkán ìtẹ́. 21 Gbé ọmọrí orí àpótí ẹ̀rí kí o sì fi ẹ̀rí èyí tí èmí yóò fi fún ọ sínú àpótí ẹ̀rí. 22 Níbẹ̀, ni òkè ìtẹ́, ní àárín kérúbù méjèèjì ti ó wà ni orí àpótí ẹ̀rí ni èmi yóò ti pàdé rẹ, ti èmi yóò sì fún ọ ní àwọn òfin mi fún àwọn ọmọ Israẹli.
Tábìlì
23 (D)“Fi igi kasia kan tábìlì: ìgbọ̀nwọ́ méjì ní gígùn ìgbọ̀nwọ́ kan ní fífẹ̀, ìgbọ̀nwọ́ kan àti ààbọ̀ ní gíga. 24 Ìwọ ó sì fi ojúlówó wúrà bò ó, ìwọ ó sì ṣe ìgbátí wúrà yí i ká. 25 Ìwọ sì ṣe etí kan ní ìbú àtẹ́lẹwọ́ sí i yíká, ó sì ṣe ìgbátí wúrà yí etí rẹ̀ ká. 26 Ìwọ ó sì da òrùka wúrà mẹ́rin fún tábìlì náà, ìwọ ó sì fi òrùka kọ̀ọ̀kan sí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tí ó wà ní ẹsẹ̀ rẹ̀ mẹ́rẹ̀ẹ̀rin. 27 Ní abẹ́ ìgbátí náà ni àwọn òrùka náà yóò wà fún ibi ọ̀pá láti máa fi gbé tábìlì náà. 28 Ìwọ ó sì fi igi kasia ṣe àwọn ọ̀pá, ìwọ ó sì fi wúrà bò wọ́n, láti máa fi wọ́n gbé tábìlì náà. 29 Ìwọ ó sì fi ojúlówó wúrà ṣe àwo àti ṣíbí rẹ̀, kí o sì ṣe àwokòtò àti ago pẹ̀lú fún dída ọrẹ jáde. 30 (E)Gbé àkàrà ìfihàn sí orí tábìlì yìí, kí ó le wà ní iwájú mi ni gbogbo ìgbà.
Ọ̀pá fìtílà
31 (F)“Ìwọ ó sì ojúlówó wúrà, lù ú dáradára, ṣe ọ̀pá fìtílà kan, ìsàlẹ̀ àti apá rẹ̀, kọ́ọ̀bù rẹ̀ ti ó dàbí òdòdó, ìṣọ àti ìtànná rẹ̀ yóò jẹ́ ara kan náà pẹ̀lú rẹ̀. 32 Ẹ̀ka mẹ́fà ni yóò yọ ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀pá fìtílà: mẹ́ta ní ẹ̀gbẹ́ kìn-ín-ní mẹ́ta ni ẹ̀gbẹ́ kejì. 33 Àwo mẹ́ta ni kí a ṣe bí ìtànná almondi, tí ó ṣọ tí ó sì tanná ni yóò wà ni ẹ̀ka kan, mẹ́ta yóò sì wà ní ẹ̀ka kejì, àti bẹ́ẹ̀ fún àwọn ẹ̀ka mẹ́fẹ̀ẹ̀fà tí ó jáde lára ọ̀pá fìtílà. 34 Ní ara ọ̀pá fìtílà ni àwo mẹ́rin ti a ṣe gẹ́gẹ́ bí òdòdó almondi ti ó ni ìṣọ àti ìtànná yóò wà. 35 Irúdì kan yóò sì wà ní abẹ́ ẹ̀ka rẹ̀ méjì àkọ́kọ́ tí ó yọ lára ọ̀pá fìtílà, irúdì kejì ó sì wà ní abẹ́ ẹ̀ka rẹ̀ méjì kejì, irúdì kẹta yóò sì wà ní abẹ́ ẹ̀ka rẹ̀ méjì kẹta: ẹ̀ka mẹ́fà ní àpapọ̀. 36 Irúdì wọn àti ẹ̀ka wọn kí ó rí bákan náà, kí gbogbo rẹ̀ kí ó jẹ́ lílù ojúlówó wúrà.
37 “Nígbà náà ni ìwọ yóò ṣe fìtílà méje. Ìwọ yóò sì gbe ka orí rẹ̀, kí wọn kí ó lè máa ṣe ìmọ́lẹ̀ sí iwájú rẹ̀. 38 Àti alumagaji rẹ̀, àti àwo alimagaji rẹ̀, kí ó jẹ́ kìkì wúrà. 39 Tálẹ́ǹtì kìkì wúrà ni ó fi ṣe é, pẹ̀lú gbogbo ohun èlò wọ̀nyí. 40 (G)Kíyèsí i, kí ìwọ kí ó ṣe wọ́n gẹ́gẹ́ bí àpẹẹrẹ wọn, ti a fi hàn ọ́ ni orí òkè.
Exodus 25
New King James Version
Offerings for the Sanctuary(A)
25 Then the Lord spoke to Moses, saying: 2 “Speak to the children of Israel, that they bring Me an [a]offering. (B)From everyone who gives it willingly with his heart you shall take My offering. 3 And this is the offering which you shall take from them: gold, silver, and bronze; 4 blue, purple, and scarlet thread, fine linen, and goats’ hair; 5 ram skins dyed red, [b]badger skins, and acacia wood; 6 (C)oil for the light, and (D)spices for the anointing oil and for the sweet incense; 7 onyx stones, and stones to be set in the (E)ephod and in the breastplate. 8 And let them make Me a (F)sanctuary,[c] that (G)I may dwell among them. 9 According to all that I show you, that is, the pattern of the tabernacle and the pattern of all its furnishings, just so you shall make it.
The Ark of the Testimony(H)
10 (I)“And they shall make an ark of acacia wood; two and a half cubits shall be its length, a cubit and a half its width, and a cubit and a half its height. 11 And you shall overlay it with pure gold, inside and out you shall overlay it, and shall make on it a molding of (J)gold all around. 12 You shall cast four rings of gold for it, and put them in its four corners; two rings shall be on one side, and two rings on the other side. 13 And you shall make poles of acacia wood, and overlay them with gold. 14 You shall put the poles into the rings on the sides of the ark, that the ark may be carried by them. 15 (K)The poles shall be in the rings of the ark; they shall not be taken from it. 16 And you shall put into the ark (L)the Testimony which I will give you.
17 (M)“You shall make a mercy seat of pure gold; two and a half cubits shall be its length and a cubit and a half its width. 18 And you shall make two cherubim of gold; of hammered work you shall make them at the two ends of the mercy seat. 19 Make one cherub at one end, and the other cherub at the other end; you shall make the cherubim at the two ends of it of one piece with the mercy seat. 20 And (N)the cherubim shall stretch out their wings above, covering the mercy seat with their wings, and they shall face one another; the faces of the cherubim shall be toward the mercy seat. 21 (O)You shall put the mercy seat on top of the ark, and (P)in the ark you shall put the Testimony that I will give you. 22 And (Q)there I will meet with you, and I will speak with you from above the mercy seat, from (R)between the two cherubim which are on the ark of the Testimony, about everything which I will give you in commandment to the children of Israel.
The Table for the Showbread(S)
23 (T)“You shall also make a table of acacia wood; two cubits shall be its length, a cubit its width, and a cubit and a half its height. 24 And you shall overlay it with pure gold, and make a molding of gold all around. 25 You shall make for it a frame of a handbreadth all around, and you shall make a gold molding for the frame all around. 26 And you shall make for it four rings of gold, and put the rings on the four corners that are at its four legs. 27 The rings shall be close to the frame, as holders for the poles to bear the table. 28 And you shall make the poles of acacia wood, and overlay them with gold, that the table may be carried with them. 29 You shall make (U)its dishes, its pans, its pitchers, and its bowls for pouring. You shall make them of pure gold. 30 And you shall set the (V)showbread on the table before Me always.
The Gold Lampstand(W)
31 (X)“You shall also make a lampstand of pure gold; the lampstand shall be of hammered work. Its shaft, its branches, its bowls, its ornamental knobs, and flowers shall be of one piece. 32 And six branches shall come out of its sides: three branches of the lampstand out of one side, and three branches of the lampstand out of the other side. 33 (Y)Three bowls shall be made like almond blossoms on one branch, with an ornamental knob and a flower, and three bowls made like almond blossoms on the other branch, with an ornamental knob and a flower—and so for the six branches that come out of the lampstand. 34 (Z)On the lampstand itself four bowls shall be made like almond blossoms, each with its ornamental knob and flower. 35 And there shall be a knob under the first two branches of the same, a knob under the second two branches of the same, and a knob under the third two branches of the same, according to the six branches that extend from the lampstand. 36 Their knobs and their branches shall be of one piece; all of it shall be one hammered piece of pure gold. 37 You shall make seven lamps for it, and (AA)they shall arrange its lamps so that they (AB)give light in front of it. 38 And its wick-trimmers and their trays shall be of pure gold. 39 It shall be made of a talent of pure gold, with all these utensils. 40 And (AC)see to it that you make them according to the pattern which was shown you on the mountain.
Footnotes
- Exodus 25:2 heave offering
- Exodus 25:5 Or dolphin
- Exodus 25:8 sacred place
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.
Scripture taken from the New King James Version®. Copyright © 1982 by Thomas Nelson. Used by permission. All rights reserved.
