Revised Common Lectionary (Semicontinuous)
Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi.
20 Kí Olúwa kí ó gbóhùn rẹ ní ọjọ́ ìpọ́njú;
kí orúkọ Ọlọ́run Jakọbu kí ó dáàbò bò ọ́.
2 Kí ó rán ìrànlọ́wọ́ sí ọ, láti ibi mímọ́
kí ó sì tì ọ́ lẹ́yìn láti Sioni wá.
3 Kí ó sì rántí gbogbo ẹbọ rẹ
kí ó sì gba ẹbọ sísun rẹ. Sela
4 Kí ó fi fún ọ gẹ́gẹ́ bi ti èrò ọkàn rẹ
kí ó sì mú gbogbo ìmọ̀ rẹ ṣẹ.
5 Àwa yóò hó fún ayọ̀ nígbà tí o bá di aṣẹ́gun
àwa yóò gbé àsíá wa sókè ní orúkọ Ọlọ́run wa.
Kí Ọlọ́run kí ó mú gbogbo ìbéèrè rẹ̀ ṣẹ.
6 Nísinsin yìí, èmi mọ̀ wí pé:
Olúwa pa ẹni ààmì òróró rẹ̀ mọ́.
Yóò gbọ́ láti ọ̀run mímọ́ rẹ̀ wá
pẹ̀lú agbára ìgbàlà ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀.
7 Àwọn mìíràn gbẹ́kẹ̀ wọn lé kẹ̀kẹ́, àwọn mìíràn gbẹ́kẹ̀ wọn lé ẹṣin,
ṣùgbọ́n àwa gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa Ọlọ́run wa.
8 Wọ́n wólẹ̀, ní eékún, wọ́n sì ṣubú,
ṣùgbọ́n àwa dìde, a sì dúró ṣinṣin.
9 Olúwa, fi ìṣẹ́gun fún ọba!
Dá wa lóhùn nígbà tí a bá ń kígbe pè!
15 (A)Èyí ni ohun tí Olúwa wí:
“A gbọ́ ohùn kan ní Rama
tí ń ṣọ̀fọ̀ pẹ̀lú ẹkún kíkorò.
Rakeli ń sọkún àwọn ọmọ rẹ̀;
kò gbà kí wọ́n tu òun nínú,
nítorí àwọn ọmọ rẹ̀ kò sí mọ́.”
16 Báyìí ni Olúwa wí:
“Dá ohùn rẹ dúró nínú ẹkún
àti ojú rẹ nínú omijé;
nítorí a ó fi èrè sí iṣẹ́ rẹ,”
ni Olúwa wí.
“Wọn ó sì padà wá láti ilẹ̀ ọ̀tá.
17 Nítorí ìrètí wà fún ọjọ́ iwájú rẹ,”
ni Olúwa wí.
“Àwọn ọmọ rẹ yóò padà wá sí ilẹ̀ wọn.
18 “Nítòótọ́, èmi ti gbọ́ ìpohùnréré Efraimu wí pé,
‘Ìwọ ti bá mi wí gẹ́gẹ́ bí ọmọ màlúù tí a kò kọ́
èmi sì ti gbọ́ ìbáwí.
Rà mí padà, èmi yóò sì yípadà,
nítorí ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run mi.
19 Lẹ́yìn tí èmi ti yípadà,
mo ronúpìwàdà,
lẹ́yìn tí èmi ti wá mọ̀,
èmi lu àyà mi.
Ojú tì mí, mo sì dààmú;
nítorí èmi gba èrè ẹ̀gàn ìgbà èwe mi.’
20 Efraimu kì í ha í ṣe ọmọkùnrin mi dáradára
tí inú mi dùn sí bí?
Bí èmi ti ń sọ̀rọ̀ sí i tó,
síbẹ̀, èmi rántí rẹ̀.
Nítorí náà, ọkàn mi ṣe ohun kan fún un,
èmi káàánú gidigidi fún un,”
ni Olúwa wí.
21 “Gbé ààmì ojú ọ̀nà dìde,
ṣe atọ́nà ààmì,
kíyèsi òpópó ọ̀nà geere
ojú ọ̀nà tí ó ń gbà.
Yípadà ìwọ wúńdíá Israẹli,
padà sí àwọn ìlú rẹ.
22 Ìwọ yóò ti ṣìnà pẹ́ tó,
ìwọ aláìṣòótọ́ ọmọbìnrin;
Olúwa yóò dá ohun tuntun lórí ilẹ̀,
ọmọbìnrin kan yóò yí ọkùnrin kan ká.”
41 (A)Nígbà tí ó sì súnmọ́ etílé, ó ṣíjú wo ìlú náà, ó sọkún sí i lórí, 42 Ó ń wí pé, “Ìbá ṣe pé ìwọ mọ̀, lónìí yìí, àní ìwọ, ohun tí í ṣe tí Àlàáfíà rẹ! Ṣùgbọ́n nísinsin yìí wọ́n pamọ́ kúrò lójú rẹ. 43 (B)Nítorí ọjọ́ ń bọ̀ fún ọ, tí àwọn ọ̀tá rẹ yóò mọ odi bèbè yí ọ ká, àní tí wọn yóò sì yí ọ ká, wọn ó sì ká ọ mọ́ níhà gbogbo. 44 (C)Wọn ó sì wó ọ palẹ̀ ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ pẹ̀lú rẹ; wọn kì yóò sì fi òkúta kan sílẹ̀ lórí ara wọn; nítorí ìwọ kò mọ ọjọ́ ìbẹ̀wò rẹ.”
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.