Print Page Options
Previous Prev Day Next DayNext

Historical

Read the books of the Bible as they were written historically, according to the estimated date of their writing.
Duration: 365 days
Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)
Version
Nahumu 1-3

Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ nípa Ninefe. Ìwé ìran Nahumu ará Elkoṣi.

Ìbínú Olúwa sí Ninefe

Ọlọ́run ń jẹ owú, ó sì ń gbẹ̀san.
    Olúwa ń gbẹ̀san, ó sì kún fún ìbínú
Olúwa ń gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá rẹ̀,
    Ìbínú rẹ̀ kò sì yí padà lórí àwọn ọ̀tá rẹ̀
(A)Olúwa lọ́ra láti bínú, ó sì tóbi ní agbára;
    Olúwa kì yóò fi àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ sílẹ̀ láìjìyà.
Ọ̀nà rẹ̀ wà nínú afẹ́fẹ́ àti nínú ìjì,
    Ìkùùkuu sánmọ̀ sì ni eruku ẹsẹ̀ rẹ̀.
Ó bá Òkun wí, ó sì mú kí ó gbẹ;
    Ó sìsọ gbogbo odò di gbígbẹ.
Baṣani àti Karmeli sì rọ,
    Ìtànná Lebanoni sì rẹ̀ sílẹ̀.
Àwọn òkè ńlá wárìrì níwájú rẹ̀,
    àwọn òkè kéékèèkéé sì di yíyọ́,
ilẹ̀ ayé sì jóná níwájú rẹ̀,
    àní ayé àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.
Ta ni ó lé dúró níwájú ìbínú rẹ̀?
    Ta ni ó lé faradà gbígbóná ìbínú rẹ̀?
Ìbínú rẹ̀ tú jáde bí iná;
    àwọn àpáta sì fọ́ túútúú níwájú rẹ̀.

Rere ni Olúwa,
    òun ni ààbò ní ọjọ́ ìpọ́njú.
Òun sì tọ́jú àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé e,
    Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìkún omi ńlá
ní òun yóò fi ṣe ìparun láti ibẹ̀ dé òpin;
    òkùnkùn yóò sì máa lépa àwọn ọ̀tá rẹ̀.

Kí ni ẹ̀yìn ń gbìmọ̀ lòdì sí Olúwa?
    Òun yóò fi òpin sí i,
    ìpọ́njú kì yóò wáyé ní ìgbà kejì
10 Wọn yóò sì lọ́lù papọ̀ bí ẹ̀gún òṣùṣú
    wọn yóò sì mu àmupara nínú ọtí wáìnì wọn
    a ó sì run wọn gẹ́gẹ́ bi àgékù koríko gbígbẹ
11 Láti ọ̀dọ̀ rẹ, ìwọ Ninefe, ni ẹnìkan ti jáde wá
    tí ó ń gbèrò ibi sí Olúwa
    ti ó sì ń gbìmọ̀ búburú.

12 Báyìí ni Olúwa wí:

“Bí wọ́n tilẹ̀ ni ìfọwọ́sowọ́pọ̀, tí wọ́n sì pọ̀ níye,
    Ṣùgbọ́n, báyìí ní a ó ké wọn lulẹ̀,
nígbà tí òun ó bá kọjá.
    Bí mo tilẹ̀ ti pọ́n ọ lójú ìwọ Juda, èmi kì yóò pọ́n ọ lójú mọ́.
13 Nísinsin yìí ni èmi yóò já àjàgà wọn kúrò ní ọrùn rẹ
    èmi yóò já ṣẹkẹ́ṣẹkẹ̀ rẹ dànù.”

14 Olúwa ti fi àṣẹ kan lélẹ̀ nítorí tìrẹ Ninefe:
    “Ìwọ kì yóò ni irú-ọmọ láti máa jẹ́ orúkọ rẹ mọ́,
Èmi yóò pa ère fínfín àti ère dídà run
    tí ó wà nínú tẹmpili àwọn ọlọ́run rẹ.
Èmi yóò wa ibojì rẹ,
    nítorí ẹ̀gbin ni ìwọ.”

15 (B)Wò ó, lórí àwọn òkè,
    àwọn ẹsẹ̀ ẹni tí ó mú ìròyìn ayọ̀ wá,
    ẹni tí ó ń kéde àlàáfíà,
Ìwọ Juda, pa àṣẹ rẹ tí ó ní ìrònú mọ́,
    kí ó sì san àwọn ẹ̀jẹ́ rẹ.
Àwọn ènìyàn búburú kì yóò sì gbóguntì ọ́ mọ́;
    wọn yóò sì parun pátápátá.

Ìṣubú Ninefe

Àwọn apanirun ti dìde sí ọ, ìwọ Ninefe
    pa ilé ìṣọ́ mọ́,
    ṣọ́ ọ̀nà náà
    di àmùrè, ẹ̀gbẹ́ rẹ kí ó le,
    múra gírí.

Olúwa yóò mú ọláńlá Jakọbu padà sípò
    gẹ́gẹ́ bí ọláńlá Israẹli
bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn apanirun ti pa ibẹ̀ run,
    tí wọ́n sì ba ẹ̀ka àjàrà wọn jẹ́.

Asà àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sì di pupa;
    àwọn ológun wọn sì wọ aṣọ òdòdó.
Idẹ tí ó wà lórí kẹ̀kẹ́ ogun ń kọ mọ̀nàmọ́ná
    ní ọjọ́ tí a bá pèsè wọn sílẹ̀ tán;
    igi firi ni a ó sì mì tìtì.
Àwọn kẹ̀kẹ́ ogun yóò ya bo àwọn pópónà,
    wọn yóò sì máa sáré síwá àti sẹ́yìn ní àárín ìgboro.
Wọn sì dàbí ètùfù iná;
    tí ó sì kọ bí i mọ̀nàmọ́ná.

Ninefe yóò ṣe àṣàrò àwọn ọlọ́lá rẹ̀;
    síbẹ̀ wọ́n ń kọsẹ̀ ní ojú ọ̀nà wọn;
wọn sáré lọ sí ibi odi rẹ̀,
    a ó sì pèsè ààbò rẹ̀.
A ó ṣí ìlẹ̀kùn àwọn odò wọ̀n-ọn-nì sílẹ̀,
    a ó sì mú ààfin náà di wíwó palẹ̀.
A pa á láṣẹ pé ìlú náà, èyí tí a ti fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀
    ni a ó sì kó ní ìgbèkùn lọ.
A ó sì mú un gòkè wá
    àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ yóò kérora bí ti ẹyẹ àdàbà,
    wọn a sì máa lu àyà wọn.
Ninefe dàbí adágún omi,
    tí omi rẹ̀ sì ń gbẹ́ ẹ lọ.
“Dúró! Dúró!” ni wọ́n ó máa kígbe,
    ṣùgbọ́n ẹnìkankan kì yóò wo ẹ̀yìn.
“Ẹ kó ìkógun fàdákà!
    Ẹ kó ìkógun wúrà!
Ìṣúra wọn ti kò lópin náà,
    àti ọrọ̀ kúrò nínú gbogbo ohun èlò ti a fẹ́!”
10 Òun ti ṣòfò, ó si di asán, ó sì di ahoro:
    ọkàn pami, eékún ń lu ara wọn,
    ìrora púpọ̀ sì wà nínú gbogbo ẹgbẹ́
    àti ojú gbogbo wọ́n sì rẹ̀wẹ̀sì.

11 Níbo ni ihò àwọn kìnnìún wà
    àti ibi ìjẹun àwọn ọmọ kìnnìún,
níbi tí kìnnìún, àní abo kìnnìún tí ń rìn,
    àti ọmọ kìnnìún, láìsí ohun ìbẹ̀rù
12 Kìnnìún tipa ọ̀pọ̀lọpọ̀ fún àwọn ọmọ rẹ̀,
    ó sì fún un ẹran ọdẹ ní ọrùn pa fún àwọn abo kìnnìún rẹ̀,
Ó sì fi ohun pípa kún ibùgbé rẹ̀
    àti ihò rẹ̀ fún ohun ọdẹ.

13 “Kíyèsi i èmi dojúkọ ọ́,”
    ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
“Èmi yóò sì fi kẹ̀kẹ́ rẹ̀ wọ̀n-ọn-nì jóná nínú èéfín,
    idà yóò sì jẹ ọmọ kìnnìún rẹ̀ wọ̀n-ọn-nì run.
    Èmi yóò sì ké ohun ọdẹ rẹ kúrò lórí ilẹ̀ ayé
Ohùn àwọn ìránṣẹ́ rẹ
    ni a kì yóò sì tún gbọ́ mọ́.”

A fi Ninefe bú

Ègbé ni fún ìlú ẹ̀jẹ̀ nì,
    gbogbo rẹ̀ kún fún èké,
ó kún fún olè,
    ìjẹ kò kúrò!
Ariwo pàṣán àti ariwo
    kíkùn kẹ̀kẹ́ ogun
àti jíjó ẹṣin
    àti gbígbọn kẹ̀kẹ́ ogun jìgìjìgì!
Ológun orí ẹṣin ń fi ìgbónára
    ju idà wọn mọ̀nàmọ́ná
    ọ̀kọ̀ rẹ̀ ti ń dán yanran sí òkè!
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ si ní àwọn ẹni tí a pa,
    àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ òkú;
òkú kò sì ni òpin;
    àwọn ènìyàn sì ń kọsẹ̀ lára àwọn òkú.
Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ panṣágà
    àgbèrè tí ó rójú rere gbà,
Ìyá àjẹ́ tí ó ṣọ́ àwọn orílẹ̀-èdè di ẹrú
    nípa àgbèrè rẹ̀
    àti àwọn ìdílé nípa ìṣe àjẹ́ rẹ̀.

“Èmi dojúkọ ọ́,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
    “Èmi ó si ká aṣọ àwọ̀tẹ́lẹ̀ rẹ ní ojú rẹ,
Èmi yóò sì fi ìhòhò rẹ̀ han àwọn orílẹ̀-èdè
    àti ìtìjú rẹ̀ han àwọn ilẹ̀ ọba.
Èmi yóò da ẹ̀gbin tí ó ni ìríra sí ọ ní ara,
    èmi yóò sì sọ ọ́ di aláìmọ́,
    èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹlẹ́yà.
Gbogbo àwọn tí ó ba sì wò ọ́ yóò sì káàánú fún ọ, wọn yóò sì wí pé,
    ‘Ninefe ṣòfò: Ta ni yóò kẹ́dùn rẹ?’
    Níbo ni èmi o ti wá olùtùnú fún ọ?”

Ǹjẹ́ ìwọ ha sàn ju Tebesi lọ,
    èyí tí ó wà ní ibi odò, Naili
    tí omi sì yí káàkiri?
Odò náà sì jẹ́ ààbò rẹ̀,
    omi si jẹ́ odi rẹ̀.
Etiopia àti Ejibiti ni agbára rẹ, kò sí ní òpin;
    Puti àti Libia ni àwọn olùgbèjà rẹ̀.
10 Síbẹ̀síbẹ̀ a kó o ní ìgbèkùn
    o sì lọ sí oko ẹrú.
Àwọn ọmọ wẹ́wẹ́ rẹ̀ ni a ó fọ́ mọ́lẹ̀
    ní orí ìta gbogbo ìgboro.
Wọ́n sì di ìbò nítorí àwọn ọlọ́lá rẹ̀ ọkùnrin,
    gbogbo àwọn ọlọ́lá rẹ ni a sì fi ẹ̀wọ̀n dè
11 Ìwọ pẹ̀lú yóò sì mu àmupara;
    a ó sì fi ọ́ pamọ́
    ìwọ pẹ̀lú yóò máa ṣe àfẹ́rí ààbò nítorí ti ọ̀tá náà.

12 Gbogbo ilé ìṣọ́ agbára rẹ yóò dàbí igi ọ̀pọ̀tọ́
    pẹ̀lú àkọ́pọ́n èso wọn;
Nígbà tí wọ́n bá ń gbọ̀n wọ́n,
    ọ̀pọ̀tọ́ yóò sì bọ́ sí ẹnu àwọn ọ̀jẹun.
13 Kíyèsi gbogbo àwọn jagunjagun!
    Obìnrin ni gbogbo wọn.
Ojú ibodè rẹ ní a ó ṣí sílẹ̀ gbagada,
    fún àwọn ọ̀tá rẹ;
    iná yóò jó ọ̀pá ìdábùú ìlẹ̀kùn ibodè rẹ.

14 Pọn omi nítorí ìhámọ́,
    mú ilé ìṣọ́ rẹ lágbára sí i
wọ inú amọ̀
    kí o sì tẹ erùpẹ̀,
    kí ó sì tún ibi tí a ti ń sun bíríkì-amọ̀ ṣe kí ó le.
15 Níbẹ̀ ni iná yóò ti jó ọ́ run;
    idà yóò sì ké ọ kúrò,
    yóò sì jẹ ọ́ bí i kòkòrò,
yóò sì sọ ara rẹ̀ di púpọ̀ bí i tata,
    àní, di púpọ̀ bí eṣú!
16 Ìwọ ti sọ àwọn oníṣòwò rẹ di púpọ̀
    títí wọn yóò fi pọ̀ ju ìràwọ̀ ojú ọ̀run lọ
Ṣùgbọ́n bi eṣú ni wọn yóò sọ ilẹ̀ náà di ahoro, wọn yóò sì fò lọ.
17 Àwọn aládé rẹ̀ dàbí eṣú,
    àwọn ọ̀gágun rẹ dàbí ẹlẹ́ǹgà ńlá,
    èyí tí ń dó sínú ọgbà ni ọjọ́ òtútù,
ṣùgbọ́n nígbà tí oòrùn jáde, wọ́n sálọ
    ẹnìkan kò sì mọ ibi tí wọ́n gbé wà.

18 Ìwọ ọba Asiria,
    àwọn olùṣọ́-àgùntàn rẹ̀ ń tòògbé;
àwọn ọlọ́lá rẹ dùbúlẹ̀ láti sinmi.
    Àwọn ènìyàn rẹ fọ́nká lórí àwọn òkè ńlá,
    tí ẹnikẹ́ni kò sì kó wọn jọ.
19 Kò sì sí ohun tí ó lè wo ọgbẹ́ ẹ̀ rẹ sàn;
    ọgbẹ́ rẹ kún fún ìrora
Gbogbo ẹni tí ó bá sì gbọ́ ìròyìn rẹ
    yóò pàtẹ́wọ́ lé ọ lórí,
nítorí ta ni kò ní pín nínú
    ìwà búburú rẹ ti kò ti lópin.

Habakuku 1-3

Àsọtẹ́lẹ̀ tí wòlíì Habakuku rí.

Ìráhùn Habakuku

(A)Olúwa, èmi yóò ti ké pẹ́ tó fún ìrànlọ́wọ́,
    Ṣùgbọ́n ti ìwọ kò ni fetí sí mi?
Tàbí kígbe sí ọ ní ti, “Ìwà ipá!”
    ṣùgbọ́n tí ìwọ kò sì gbàlà?
Èéṣe tí ìwọ fi mú mi rí àìṣedéédéé
    Èéṣe tí ìwọ sì fi ààyè gba ìwà ìkà?
Ìparun àti ìwà ipá wà ní iwájú mi;
    ìjà ń bẹ, ìkọlù sì wà pẹ̀lú.
Nítorí náà, òfin di ohun àìkàsí,
    ìdájọ́ òdodo kò sì borí.
Àwọn ẹni búburú yí àwọn olódodo ká,
    Nítorí náà ni ìdájọ́ òdodo ṣe yí padà.

Ìdáhùn Olúwa

(B)“Ẹ wo inú àwọn kèfèrí, ki ẹ sí wòye,
    Kí háà kí ó sì ṣe yin gidigidi.
Nítorí èmi ó ṣe ohun kan ní ọjọ́ yín
    tí ẹ̀yin kò jẹ́ gbàgbọ́,
    bí a tilẹ̀ sọ fún yin.
(C)Nítorí pé, èmi yóò gbé àwọn ara Babeli dìde,
    àwọn aláìláàánú àti onínú-fùfù ènìyàn
tí ó rin gbogbo ilẹ̀ ayé já
    láti fi agbára gbà àwọn ibùgbé tí kì í ṣe tiwọn.
Wọn jẹ́ ènìyàn ti a bẹ̀rù, tí a sì páyà,
    ìdájọ́ wọn, àti ọláńlá wọn,
    Yóò máa ti inú wọn jáde.
Ẹṣin wọn yára ju ẹkùn lọ,
    wọ́n sì gbóná jú ìkookò àṣálẹ́ lọ
àwọn ẹlẹ́ṣin wọn yóò sí tan ara wọn ká;
    wọn yóò sì wá láti ọ̀nà jíjìn réré,
wọn yóò sí fò bí ẹyẹ igún tí ń wá láti jẹrun
    Gbogbo wọn sì wà fún ìwà ipá
ìwò ojú wọn yóò sì wá síwájú;
    wọn sì ko ìgbèkùn jọ bí iyanrìn.
10 Wọn ó si máa fi àwọn ọba ṣẹ̀sín
    wọn ó sì tún kẹ́gàn àwọn aládé.
Wọn yóò sì fi gbogbo ìlú odi alágbára nì rẹ́rìn-ín;
    Nítorí pé, wọn yóò ko erùpẹ̀ jọ, wọn yóò sì gbà á
11 Nígbà náà ni inú rẹ̀ yóò yípadà,
    yóò sì rékọjá, yóò si ṣẹ̀ ní kíka agbára rẹ̀ yìí sí iṣẹ́ òrìṣà rẹ̀.”

Ìráhùn lẹ́ẹ̀kejì Habakuku

12 Olúwa, ǹjẹ́ láti ayérayé kọ ni ìwọ tí wà?
    Olúwa Ọlọ́run mi. Ẹni mímọ́ mi, àwa kì yóò kú
Olúwa, ìwọ tí yàn wọn fún ìdájọ́;
    Ọlọ́run alágbára, ìwọ tí fi ẹsẹ̀ wọn múlẹ̀ fún ìbáwí
13 Ojú rẹ mọ́ tónítóní láti wo ibi;
    ìwọ kò le gbà ìwà ìkà
nítorí kí ni ìwọ ṣe gba àwọn alárékérekè láààyè?
    Nítorí kí ni ìwọ ṣe dákẹ́ nígbà tí ẹni búburú ń pa
    ẹni tí i ṣe olódodo ju wọn lọ run?
14 Ìwọ sì tí sọ ènìyàn di bí ẹja inú Òkun,
    bí ohun tí ń rákò tí wọn ko ni alákòóso
15 Àwọn ènìyàn búburú fi àwọ̀n wọn gbé wọn sókè
    ó sì kó wọn jọ nínú àwọ̀n ńlá rẹ̀;
    nítorí náà, ó dunnú, ó sì yọ̀ pẹ̀lú.
16 Nítorí náà, ó rú ẹbọ sí àwọ̀n rẹ̀,
    ó sì ń sun tùràrí fún àwọ̀n ńlá rẹ̀
nítorí pẹ̀lú àwọ̀n rẹ̀ ni ó fi ń gbé ní ìgbádùn
    tí ó sì ń gbádùn pẹ̀lú oúnjẹ tí ó bá wù ú.
17 Ǹjẹ́ wọn yóò ha máa pa àwọ̀n wọn mọ́ ní òfìfo bí,
    tí wọn yóò sì pa orílẹ̀-èdè run láìsí àánú?

Ìdáhùn Ọlọ́run sí ìráhùn wòlíì Habakuku

(D)Èmi yóò dúró lórí ibusọ́ mi láti máa wòye
    Èmi yóò sì gbé ara mi ka orí alóre
Èmi yóò si ṣọ́ láti gbọ́ ohun tí yóò sọ fún mi
    àti èsì ti èmi yóò fún ẹ̀sùn yìí nígbà tó bá ń bá mi wí.

Ìdáhùn Olúwa

Nígbà náà ni Olúwa dáhùn pé:

“Kọ ìṣípayá náà sílẹ̀
    kí o sì fi hàn ketekete lórí wàláà
    kí ẹni tí ń kà á, lè máa sáré.
(E)Nítorí ìṣípayá náà jẹ́ tí ìgbà kan tí a múra sílẹ̀ dè;
    yóò máa yára sí ìgbẹ̀yìn
    kí yóò sìsọ èké.
Bí o tilẹ̀ lọ́ra, dúró dè é;
    nítorí, dájúdájú, yóò dé, kí yóò sí pẹ́.”

(F)“Kíyèsi, ọkàn rẹ tí ó gbéga;
    Ìfẹ́ rẹ̀ kò dúró ṣinṣin nínú rẹ̀,
    ṣùgbọ́n olódodo yóò wa nípa ìgbàgbọ́ rẹ̀.
Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lú, nítorí tí ọtí wáìnì ni ẹ̀tàn,
    agbéraga ènìyàn òun, kò sì ní sinmi
ẹni tí ó sọ ìwọra rẹ di gbígbòòrò bí isà òkú,
    ó sì dàbí ikú, a kò sì le tẹ́ ẹ lọ́rùn,
ó kó gbogbo orílẹ̀-èdè jọ sí ọ̀dọ̀
    ó sì gba gbogbo ènìyàn jọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀.

“Gbogbo àwọn wọ̀nyí kì yóò máa pa òwe sí i tí wọn yóò sì máa kọ orin òwe sí i wí pé,

“ ‘Ègbé ni fún ẹni tí ń mu ohun tí kì í ṣe tirẹ̀ pọ̀ sí i!
    Tí ó sì sọ ara rẹ̀ di ọlọ́rọ̀ nípasẹ̀ ìlọ́nilọ́wọ́gbà!
    Eléyìí yóò ha ti pẹ́ tó?’
Ǹjẹ́ ẹni ti ó yọ ọ́ lẹ́nu, kí yóò ha dìde ní òjijì?
    Àti àwọn tí ó wàhálà rẹ kì yóò jí, kí wọn ó sì dẹ́rùbà ọ́?
    Nígbà náà ni ìwọ yóò wa dí ìkógun fún wọn.
Nítorí ìwọ ti kó orílẹ̀-èdè púpọ̀,
    àwọn ènìyàn tókù yóò sì kó ọ
nítorí ìwọ tí ta ẹ̀jẹ̀ ènìyàn sílẹ̀; nítorí ẹ̀jẹ̀
    Ìwọ tí pa ilẹ̀ àti ìlú ńlá run
    àti gbogbo ènìyàn to ń gbé inú rẹ̀.

“Ègbé ni fún ẹni tí ń jẹ èrè ìjẹkújẹ sí ilé rẹ̀,
    tí o sí gbé ìtẹ́ rẹ̀ lórí ibi gíga,
    kí a ba le gbà á sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ibi!
10 Ìwọ ti gbìmọ̀ ìtìjú sí ilé rẹ
    nípa kíké ènìyàn púpọ̀ kúrò;
    ìwọ sì ti pàdánù ẹ̀mí rẹ
11 Nítorí tí òkúta yóò kígbe jáde láti inú ògiri wá,
    àti ìtí igi láti inú igi rírẹ́ wá yóò sì dá a lóhùn.

12 “Ègbé ni fún ẹni tí ó fi ẹ̀jẹ̀ kọ́ ìlú,
    tí o sì fi àìṣedéédéé tẹ ìlú ńlá dó?
13 Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun kò ha ti ṣètò rẹ̀ pé
    làálàá àwọn ènìyàn jẹ́ epo fún iná
    kí àwọn orílẹ̀-èdè náà sì máa ṣe wàhálà fún asán?
14 Nítorí tí ayé yóò kún fún ìmọ̀ ògo Olúwa,
    bí omi ti bo Òkun.

15 “Ègbé ni fún ẹni tí ó fi ohun mímu fún aládùúgbò rẹ̀,
    tí ó sì fi ọtí-lílé rẹ̀ fún un, tí o sì jẹ́ kó mu àmupara,
    kí ìwọ kí ó ba lè wo ìhòhò wọn”
16 Ìtìjú yóò bò ọ́ dípò ògo, ìwọ náà mu pẹ̀lú
    kí ìhòhò rẹ kí ó lè hàn,
ago ọwọ́ ọ̀tún Olúwa, yóò yípadà sí ọ,
    ìtìjú yóò sì bo ògo rẹ.
17 Nítorí ìwà ipá tí ó tí hù sí Lebanoni yóò bò ọ́,
    àti ìparun àwọn ẹranko yóò dẹ́rùbà ọ́ mọ́lẹ̀
Nítorí ìwọ tí ta ẹ̀jẹ̀ ènìyàn sílẹ̀;
    ìwọ tí pa ilẹ̀ náà àti ìlú ńlá run àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.

18 “Èrè kí ni òrìṣà ni, tí oníṣọ̀nà rẹ̀ fi gbẹ́ ẹ,
    ère dídá ti ń kọ ni èké?
Nítorí ti ẹni ti ó dá a gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé ohun tí ó fúnrarẹ̀ dá;
    ó sì mọ ère tí kò le fọhùn.
19 Ègbé ni fún ẹni ti ń sọ fún igi pé, ‘di alààyè?’
    Fún òkúta tí kò lè fọhùn pé, ‘Dìde’
Ǹjẹ́ òun lè tọ́ ni sí ọ̀nà?
    Wúrà àti fàdákà ni a fi bò ó yíká;
    kò sì sí èémí kan nínú rẹ.”

20 (G)Ṣùgbọ́n Olúwa wà nínú tẹmpili mímọ́ rẹ̀;
    Ẹ jẹ́ kí gbogbo ayé parọ́rọ́ níwájú rẹ.

Àdúrà Habakuku

Àdúrà wòlíì Habakuku gẹ́gẹ́ bí sígónótì. Ohun èlò orin.

Olúwa mo tí gbọ́ ohùn rẹ;
    ẹ̀rù sì ba mi fún iṣẹ́ rẹ Olúwa
sọ wọn di ọ̀tún ní ọjọ́ ti wa,
    ní àkókò tiwa, jẹ́ kó di mí mọ̀;
    ni ìbínú, rántí àánú.

Ọlọ́run yóò wa láti Temani,
    ibi mímọ́ jùlọ láti Òkè Parani
ògo rẹ̀ sí bo àwọn ọ̀run,
    ilé ayé sì kún fún ìyìn rẹ
Dídán rẹ sí dàbí ìmọ́lẹ̀ oòrùn
    ìtànṣán ìmọ́lẹ̀ jáde wa láti ọwọ́ rẹ,
    níbi tí wọn fi agbára rẹ̀ pamọ́ sí.
Àjàkálẹ̀-ààrùn ń lọ ni iwájú rẹ;
    ìyọnu sí ń tọ ẹsẹ̀ rẹ lọ.
Ó dúró, ó sì mi ayé;
    ó wò, ó sì mú àwọn orílẹ̀-èdè wárìrì
a sì tú àwọn òkè ńlá ayérayé ká,
    àwọn òkè kéékèèkéé ayérayé sì tẹríba:
    ọ̀nà rẹ ayérayé ni.
Mo rí àgọ́ Kuṣani nínú ìpọ́njú
    àti àwọn ibùgbé Midiani nínú ìrora.

Ǹjẹ́ ìwọ ha ń bínú sí àwọn Odò nì, Olúwa?
    Ǹjẹ́ ìbínú rẹ wa lórí àwọn odò ṣíṣàn bí?
Ìbínú rẹ ha wá sórí Òkun
    tí ìwọ fi ń gun ẹṣin,
    àti kẹ̀kẹ́ ìgbàlà rẹ?
A ṣí ọrun rẹ sílẹ̀ pátápátá,
    gẹ́gẹ́ bí ìbúra àwọn ẹ̀yà, àní ọ̀rọ̀ rẹ,
ìwọ sì fi odò pín ilẹ̀ ayé.
10     Àwọn òkè ńlá ri ọ wọn sì wárìrì
àgbàrá òjò ń sàn án kọjá lọ;
    ibú ń ké ramúramù
    ó sì gbé irú omi sókè.

11 Òòrùn àti Òṣùpá dúró jẹ́ẹ́jẹ́ ni ibùgbé wọn,
    pẹ̀lú ìmọ́lẹ̀ ọfà rẹ ni wọn yára lọ,
    àti ni dídán ọ̀kọ̀ rẹ ti ń kọ mànà.
12 Ní ìrunú ni ìwọ rin ilẹ̀ náà já,
    ní ìbínú ni ìwọ tí tẹ́ àwọn orílẹ̀-èdè rẹ.
13 Ìwọ jáde lọ láti tú àwọn ènìyàn rẹ sílẹ̀,
    àti láti gba ẹni ààmì òróró rẹ là;
Ìwọ ti run àwọn olórí kúrò nínú ilẹ̀ àwọn ènìyàn búburú,
    ó sì bọ ìhámọ́ra rẹ láti orí de ẹsẹ̀
14 Pẹ̀lú ọ̀kọ̀ rẹ̀ kí ó fi gún orí rẹ
    nígbà tí àwọn jagunjagun rẹ̀
jáde láti tú wá ká:
    ayọ̀ wọn sì ni láti jẹ tálákà run ní ìkọ̀kọ̀.
15 Ìwọ fi ẹṣin rẹ rìn Òkun já,
    ó sì da àwọn omi ńlá ru.

16 Mo gbọ́, ọkàn mi sì wárìrì,
    ètè mi sì gbọ̀n sí ìró náà;
ìbàjẹ́ sì wọ inú egungun mi lọ,
    ẹsẹ̀ mi sì wárìrì,
mo dúró ni ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ fún ọjọ́ ìdààmú
    láti de sórí àwọn ènìyàn tó ń dojúkọ wá.
17 Bí igi ọ̀pọ̀tọ́ ko tilẹ̀ tanná,
    tí èso kò sí nínú àjàrà;
tí igi olifi ko le so,
    àwọn oko ko sì mú oúnjẹ wá;
tí a sì ké agbo ẹran kúrò nínú agbo,
    tí kò sì sí ọwọ́ ẹran ni ibùso mọ́,
18 síbẹ̀, èmi ó láyọ̀ nínú Olúwa,
    èmi yóò sí máa yọ nínú Ọlọ́run ìgbàlà mi.

19 Olúwa Olódùmarè ni agbára mi,
    òun yóò sí ṣe ẹsẹ̀ mi bí ẹsẹ̀ abo àgbọ̀nrín,
    yóò sí mú mi rìn lórí ibi gíga.

Sí olórí akọrin lórí ohun èlò orin olókùn mi.

Bíbélì Mímọ́ Yorùbá Òde Òn (BYO)

Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.