Beginning
Isakari
7 Àwọn ọmọ Isakari:
Tola, Pua, Jaṣubu àti Ṣimroni, mẹ́rin ni gbogbo rẹ̀.
2 Àwọn ọmọ Tola:
Ussi, Refaiah, Jehieli, Jamai, Ibsamu àti Samuẹli olórí àwọn ìdílé wọn. Ní àkókò ìjọba, Dafidi, àwọn ìran ọmọ Tola tò lẹ́sẹẹsẹ gẹ́gẹ́ bí àwọn ọkùnrin alágbára ní ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn, tí iye wọn sì jẹ́ ẹgbàá-mọ́kànlá ó-lé-ẹgbẹ̀ta (22,600).
3 Àwọn ọmọ, Ussi:
Israhiah.
Àwọn ọmọ Israhiah:
Mikaeli, Ọbadiah, Joeli àti Iṣiah. Gbogbo àwọn márààrún sì jẹ́ olóyè. 4 Gẹ́gẹ́ bí ìtàn ìdílé wọn láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn, wọ́n ní ọkùnrin ẹgbàá-mẹ́rìndínlógójì tí ó ti ṣe tan fún ogun, nítorí wọ́n ní ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ àti ìyàwó.
5 Àwọn ìbátan tí ó jẹ́ alágbára akọni àwọn ọkùnrin tí ó jẹ́ ti àwọn ìdílé Isakari, bí a ti tò ó lẹ́sẹẹsẹ nínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn jẹ́ ẹgbàá-mẹ́tàdínláàádọ́rin (87,000) ni gbogbo rẹ̀.
Benjamini
6 Àwọn ọmọ mẹ́ta Benjamini:
Bela, Bekeri àti Jediaeli.
7 Àwọn ọmọ Bela:
Esboni, Ussi, Usieli, Jerimoti àti Iri, àwọn márààrún. Àwọn ni olórí ilé baba ńlá wọn, akọni alágbára ènìyàn. A sì ka iye wọn nípa ìran wọn sí ẹgbàá-mọ́kànlá ó-lé-mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n ènìyàn (22,034).
8 Àwọn ọmọ Bekeri:
Semirahi, Joaṣi, Elieseri, Elioenai, Omri, Jeremoti, Abijah, Anatoti àti Alemeti. Gbogbo wọ̀nyí jẹ́ ọmọ Bekeri 9 Ìtàn ìdílé wọn láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn tí a kọ lẹ́sẹẹsẹ jẹ́ ti àwọn olórí ìdílé àti ẹgbẹ̀rún ní ọ̀nà ogún ó-lé-nígba (20,200) ọkùnrin alágbára.
10 Ọmọ Jediaeli:
Bilhani.
Àwọn ọmọ Bilhani:
Jeuṣi Benjamini, Ehudu, Kenaana, Setamu, Tarṣiṣi àti Ahiṣahari. 11 Gbogbo àwọn ọmọ Jediaeli jẹ́ olórí. Àwọn ẹgbẹ̀rúnmẹ́tà-dínlógún ó-lé-nígba akọni ọkùnrin ni ó ti ṣetán láti jáde lọ sí ogun.
12 Àti Ṣuppimu, àti Huppimu, àwọn ọmọ Iri, àti Huṣimu, àwọn ọmọ Aheri.
Naftali
13 Àwọn ọmọ Naftali:
Jasieli, Guni, Jeseri àti Ṣallumu—ọmọ rẹ̀ nípa Biliha.
Manase
14 Àwọn ìran ọmọ Manase:
Asrieli jẹ́ ìran ọmọ rẹ̀ ní ipasẹ̀ àlè rẹ̀ ará Aramu ó bí Makiri baba Gileadi. 15 Makiri sì mú ìyàwó láti àárín àwọn ará Huppimu àti Ṣuppimu. Orúkọ arábìnrin rẹ̀ a máa jẹ́ Maaka. Orúkọ ìran ọmọ mìíràn a máa jẹ́ Ṣelofehadi, tí ó ní àwọn ọmọbìnrin nìkan ṣoṣo. 16 Maaka, ìyàwó Makiri bí ọmọkùnrin kan. Ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Peresi. Ó sì pe arákùnrin rẹ̀ ní Ṣereṣi, àwọn ọmọ rẹ̀ sì ní Ulamu àti Rakemu.
17 Ọmọ Ulamu:
Bedani.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Gileadi ọmọ Makiri, ọmọ Manase.
18 Arábìnrin rẹ̀. Hamoleketi bí Iṣhodi, Abieseri àti Mahila.
19 Àwọn ọmọ Ṣemida sì jẹ́:
Ahiani, Ṣekemu, Likki àti Aniamu.
Efraimu
20 Àwọn ìran ọmọ Efraimu:
Ṣutelahi, Beredi ọmọkùnrin rẹ̀,
Tahati ọmọ rẹ̀, Eleadah ọmọ rẹ̀.
Tahati ọmọ rẹ̀ 21 Sabadi ọmọ, rẹ̀,
àti Ṣutelahi ọmọ rẹ̀.
Eseri àti Eleadi ni a pa nípasẹ̀ àwọn ọkùnrin bíbí ìbílẹ̀ Gati Nígbà tí wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ láti lọ fi agbára mú ohun ọ̀sìn wọn 22 Efraimu baba wọn ṣọ̀fọ̀ fún wọn ní ọjọ́ púpọ̀, àwọn ìbátan rẹ̀ wá láti tù ú nínú. 23 Nígbà náà, ó sùn pẹ̀lú, ìyàwó rẹ̀, ó sì lóyún ó sì bí ọmọkùnrin kan. Ó sì sọ ọ́ ní Beriah nítorí òfò ti wà nínú ìdílé náà. 24 Ọmọbìnrin rẹ̀ sì jẹ́ Ṣerah, ẹni tí ó kọ́ ìsàlẹ̀ àti òkè Beti-Horoni àti Useni-Ṣerah pẹ̀lú.
25 Refa jẹ́ ọmọ rẹ̀, Resefi ọmọ rẹ̀,
Tela ọmọ rẹ̀, Tahani ọmọ rẹ̀,
26 Laadani ọmọ rẹ̀ Ammihudu ọmọ rẹ̀,
Eliṣama ọmọ rẹ̀, 27 Nuni ọmọ rẹ̀
àti Joṣua ọmọ rẹ̀.
28 Ilẹ̀ wọn àti ìfìdíkalẹ̀ wọn ni Beteli àti àwọn ìletò tí ó yíká, Narani lọ sí ìhà ìlà-oòrùn, Geseri àti àwọn ìletò rẹ̀ lọ sí ìhà ìwọ̀-oòrùn àti Ṣekemu àti àwọn ìletò rẹ̀ ní ọ̀nà lọ sí Ayahi àti àwọn ìletò. 29 Lẹ́gbẹ̀ ìpínlẹ̀ ti Manase ni Beti-Ṣeani, Taanaki, Megido àti Dori lápapọ̀ pẹ̀lú àwọn ìletò rẹ̀. Àwọn ìran ọmọ Josẹfu ọmọ Israẹli ń gbé nínú ìlú wọ̀nyí.
Aṣeri
30 Àwọn ọmọ Aṣeri:
Imina, Iṣifa, Iṣfi àti Beriah. Arábìnrin wọn sì jẹ́ Sera.
31 Àwọn ọmọ Beriah:
Heberi àti Malkieli, tí ó jẹ́ baba Barsafiti.
32 Heberi jẹ́ baba Jafileti, Ṣomeri àti Hotami àti ti arábìnrin wọn Ṣua.
33 Àwọn ọmọ Jafileti:
Pasaki, Bimhali àti Asifati.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Jafileti.
34 Àwọn ọmọ Ṣomeri:
Ahi, Roga, Jahuba àti Aramu.
35 Àwọn ọmọ arákùnrin rẹ̀ Helemu
Ṣofahi, Imina, Ṣeleṣi àti Amali.
36 Àwọn ọmọ Ṣofahi:
Sua, Haniferi, Ṣuali, Beri, Imra. 37 Beseri, Hodi, Ṣama, Ṣilisa, Itrani àti Bera.
38 Àwọn ọmọ Jeteri:
Jefunne, Pisifa àti Ara.
39 Àwọn ọmọ Ulla:
Arah, Hannieli àti Reṣia.
40 Gbogbo wọ̀nyí jẹ́ ìran ọmọ Aṣeri—olórí ìdílé, àṣàyàn ọkùnrin, alágbára jagunjagun àti olórí nínú àwọn ìjòyè. Iye àwọn tí a kà yẹ fún ogun, gẹ́gẹ́ bí à ti ṣe kọ ọ́ lẹ́sẹẹsẹ nínú ìtàn ìdílé wọn jẹ́ ẹgbàá-mẹ́tàlá (26,000) ọkùnrin.
Ìtàn Ìdílé láti Ọ̀dọ̀ Baba Ńlá ti Saulu ará Benjamini
8 Benjamini jẹ́ baba:
Bela àkọ́bí rẹ̀,
Aṣbeli ọmọkùnrin ni ẹ̀ẹ̀kejì, Ahara ẹ̀ẹ̀kẹ́ta,
2 Noha ẹ̀ẹ̀kẹrin àti Rafa ẹ̀ẹ̀karùnún.
3 Àwọn ọmọ Bela jẹ́:
Adari, Gera, Abihudi, 4 Abiṣua, Naamani, Ahoa, 5 Gera, Ṣefufani àti Huramu.
6 Wọ̀nyí ni àwọn ìran ọmọ Ehudu, tí wọ́n jẹ́ olórí àwọn ìdílé tí ó ń gbé ní Geba tí a sì lé kúrò lọ sí Manahati:
7 Naamani Ahijah àti Gera, tí ó lé wọn kúrò ní ìlú, àti tí ó sì jẹ́ baba Ussa àti Ahihudu.
8 A bí àwọn ọmọkùnrin fún Ṣaharaimu ní Moabu lẹ́yìn tí ó ti kọ àwọn ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀, Huṣimu àti Baara. 9 Nípasẹ̀ ìyàwó rẹ̀ Hodeṣi ó ní Jobabu Ṣibia, Meṣa, Malkamu, 10 Jeusi, Sakia àti Mirma. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin rẹ̀, olórí àwọn ìdílé. 11 Nípasẹ̀ Huṣimu ó ní Abitubu àti Elipali.
12 Àwọn ọmọ Elipali:
Eberi, Miṣamu, Ṣemedu (ẹni tí ó kọ́ Ono àti Lodi pẹ̀lú àwọn ìletò àyíká rẹ̀.) 13 Pẹ̀lú Beriah àti Ṣema, tí wọ́n jẹ́ olórí àwọn ìdílé ti àwọn tí ó ń gbé ní Aijaloni àti àwọn tí ó lé àwọn olùgbé Gati kúrò.
14 Ahio, Ṣasaki, Jeremoti, 15 Sebadiah, Aradi, Ederi 16 Mikaeli, Iṣifa àti Joha jẹ́ àwọn ọmọ Beriah.
17 Sebadiah, Meṣullamu, Hiski, Heberi 18 Iṣimerai, Isiliahi àti Jobabu jẹ́ àwọn ọmọ Elipali.
19 Jakimu, Sikri, Sabdi, 20 Elienai, Siletai, Elieli, 21 Adaiah, Beraiah àti Ṣimrati jẹ́ àwọn ọmọ, Ṣimei.
22 Iṣipani Eberi, Elieli, 23 Abdoni, Sikri, Hanani, 24 Hananiah, Elamu, Anitotijah, 25 Ifediah àti Penueli jẹ́ àwọn ọmọ Ṣasaki.
26 Ṣamṣerai, Ṣeharaiah, Ataliah 27 Jareṣiah, Elijah àti Sikri jẹ́ àwọn ọmọ Jerohamu.
28 Gbogbo àwọn wọ̀nyí jẹ́ olórí àwọn ìdílé, olóyè gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ lẹ́sẹẹsẹ nínú ìtàn ìran wọn, wọ́n sì ń gbé ní Jerusalẹmu.
29 Jeieli, baba Gibeoni ń gbé ní Gibeoni.
Ìyàwó o rẹ̀ a má jẹ́ Maaka, 30 Àkọ́bí rẹ̀ a sì máa jẹ́ Abdoni wọ̀nyí sì ń tẹ̀lé Suri, Kiṣi, Baali, Neri, Nadabu, 31 Gedori Ahio, Sekeri 32 Pẹ̀lú Mikiloti, tí ó jẹ́ baba Ṣimea. Wọ́n ń gbé ní ẹ̀bá ìbátan wọn ní Jerusalẹmu.
33 Neri jẹ́ baba Kiṣi, Kiṣi baba Saulu àti Saulu baba Jonatani, Malikiṣua, Abinadabu àti Eṣi-Baali.
34 Ọmọ Jonatani:
Meribu-Baali tí ó jẹ́ baba Mika.
35 Àwọn ọmọ Mika:
Pitoni, Meleki, Tarea, àti Ahasi.
36 Ahasi jẹ́ baba a Jeheada, Jeheada jẹ́ baba a Alemeti, Asmafeti àti Simri, Simri sì jẹ́ baba Mosa. 37 Mosa jẹ́ baba Binea; Rafa sì jẹ́ ọmọ rẹ̀, Eleasa ọmọ rẹ̀ àti Aseli ọmọ rẹ̀.
38 Aseli ní ọmọ mẹ́fà pẹ̀lú wọ̀nyí ni orúkọ wọn:
Asrikamu, Bokeru, Iṣmaeli, Ṣeariah, Ọbadiah àti Hanani. Gbogbo wọ̀nyí ni ọmọ Aseli.
39 Àwọn ọmọ arákùnrin rẹ̀ Eseki:
Ulamu àkọ́bí rẹ̀, Jeuṣi ọmọkùnrin ẹ̀ẹ̀kejì àti Elifeleti ẹ̀ẹ̀kẹ́ta. 40 Àwọn ọmọ Ulamu jẹ́ ògboyà jagunjagun tí ó lè gbá orin mú. Wọ́n ní ọ̀pọ̀ ọmọkùnrin àti ọmọ ọmọkùnrin márùn-dínlọ́gọ́jọ ní gbogbo rẹ̀.
Gbogbo wọ̀nyí ni àwọn ìdílé ìran ọmọ Benjamini.
Copyright: Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc. A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé. Yoruba Contemporary Bible Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.® Used by permission of Biblica, Inc.® All rights reserved worldwide.