Add parallel Print Page Options

Ọjọ́ iwájú Jerusalẹmu

Ègbé ni fún ìlú aninilára,
    ọlọ̀tẹ̀ àti aláìmọ́.
Òun kò gbọ́rọ̀ sí ẹnikẹ́ni,
    òun kò gba ìtọ́ni,
òun kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa,
    bẹ́ẹ̀ ni òun kò súnmọ́ ọ̀dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀.
Àwọn olórí rẹ̀ jẹ́ kìnnìún tí ń ké ramúramù,
    àwọn onídàájọ́ rẹ̀, ìkookò àṣálẹ́ ni wọn,
    wọn kò sì fi nǹkan kan kalẹ̀ fún òwúrọ̀.
Àwọn wòlíì rẹ̀ gbéraga,
    wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ènìyàn.
Àwọn àlùfáà rẹ̀ ti ba ibi mímọ́ jẹ́,
    wọ́n sì rú òfin.
Olúwa ni àárín rẹ̀ jẹ́ olódodo;
    kì yóò ṣe ohun tí kò tọ̀nà.
Àràárọ̀ ni ó máa ń mú ìdájọ́ rẹ̀ wá sí ìmọ́lẹ̀,
    kì í sì kùnà ní gbogbo ọjọ́ tuntun,
    síbẹ̀ àwọn aláìṣòótọ́ kò mọ ìtìjú.
“Èmi ti ké àwọn orílẹ̀-èdè kúrò,
    ilé gíga wọn sì ti bàjẹ́.
Mo ti fi ìgboro wọn sílẹ̀ ní òfo
    tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnìkankan kò kọjá níbẹ̀.
Ìlú wọn parun tó bẹ́ẹ̀ tí kò sí
    ẹnìkan tí yóò ṣẹ́kù,
    kò sì ní sí ẹnìkan rárá.
Èmi wí fún ìlú náà wí pé
    ‘Nítòótọ́, ìwọ yóò bẹ̀rù mi,
    ìwọ yóò sì gba ìtọ́ni!’
Bẹ́ẹ̀ ni, a kì yóò ké ibùgbé rẹ̀ kúrò
    bí ó ti wù kí ń jẹ wọ́n ní yà tó.
Ṣùgbọ́n síbẹ̀ wọ́n sì tún ní ìtara
    láti ṣe ìbàjẹ́.
Nítorí náà ẹ dúró dè mí,” ni Olúwa wí,
    “títí di ọjọ́ náà tí èmi yóò fi jẹ́rìí sí yin;
nítorí ìpinnu mi ni láti kó orílẹ̀-èdè jọ
    kí èmi kí ó lè kó ilẹ̀ ọba jọ
àti láti da ìbínú mi jáde sórí wọn,
    àní gbogbo ìbínú gbígbóná mi.
Nítorí, gbogbo ayé
    ni a ó fi iná owú mi jẹ run.

“Nígbà náà ni èmi yóò yí èdè àwọn ènìyàn padà sí èdè mímọ́,
    nítorí kí gbogbo wọn bá a lè máa pe orúkọ Olúwa,
    láti fi ọkàn kan sìn ín.
10 Láti òkè odò Etiopia,
    àwọn olùjọsìn mi, àwọn ènìyàn mi tí ó ti fọ́nká,
    yóò mú ọrẹ wá fún mi.
11 Ní ọjọ́ náà ni a kì yóò sì dójútì
    nítorí gbogbo iṣẹ́ ibi ni tí ó ti ṣẹ̀ sí mi,
nígbà náà ni èmi yóò mu
    kúrò nínú ìlú yìí, àwọn tí ń yọ̀ nínú ìgbéraga wọn.
Ìwọ kì yóò sì gbéraga mọ́
    ní òkè mímọ́ mi.
12 Ṣùgbọ́n Èmi yóò fi àwọn ọlọ́kàn tútù
    àti onírẹ̀lẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú ni àárín rẹ̀,
    wọn yóò sì gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa.
13 Àwọn ìyókù Israẹli kì yóò hùwà
    ibi, wọn kì yóò sọ̀rọ̀ èké,
    bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò rí ahọ́n àrékérekè ní
ẹnu wọn. Àwọn yóò jẹun, wọn yóò sì dùbúlẹ̀,
    bẹ́ẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kì yóò dẹ́rùbà wọ́n.”

14 Kọrin, ìwọ ọmọbìnrin Sioni,
    kígbe sókè, ìwọ Israẹli!
Fi gbogbo ọkàn yọ̀, kí inú rẹ kí ó sì dùn,
    ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu.
15 Olúwa ti mú ìdájọ́ rẹ wọ̀n-ọn-nì
    kúrò, ó sì ti ti àwọn ọ̀tá rẹ padà sẹ́yìn.
Olúwa, ọba Israẹli wà pẹ̀lú rẹ,
    Ìwọ kì yóò sì bẹ̀rù ibi kan mọ́.
16 Ní ọjọ́ náà, wọn yóò sọ fún Jerusalẹmu pé,
    “Má ṣe bẹ̀rù Sioni;
    má sì ṣe jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó dẹ̀.
17 Olúwa Ọlọ́run rẹ wà pẹ̀lú rẹ,
    Ó ní agbára láti gbà ọ là.
Yóò yọ̀ ni orí rẹ fún ayọ̀;
    Yóò tún ọ ṣe nínú ìfẹ́ rẹ̀,
    Yóò sì fi orin yọ̀ ní orí rẹ.”

18 “Èmi ó kó àwọn tí ó ń banújẹ́ fún àjọ̀dún tí a yàn jọ,
    àwọn tí ó jẹ́ tirẹ̀;
    àwọn tí ẹ̀gàn rẹ̀ jásí ẹ̀rù.
19 Ní àkókò náà
    ni èmi yóò dojúkọ àwọn
tí ń ni yín lára,
    èmi yóò gba àtiro là,
èmi yóò sì ṣa àwọn tí ó ti fọ́nká jọ,
    èmi yóò fi ìyìn àti ọlá fún wọn ní
    gbogbo ilẹ̀ tí a bá ti dójútì wọ́n.
20 Ní àkókò náà ni èmi yóò ṣà yín jọ;
    Nígbà náà ni èmi yóò mú un yín padà wá sílé.
Èmi yóò fi ọlá àti ìyìn fún un yín
    láàrín gbogbo ènìyàn àgbáyé,
nígbà tí èmi yóò yí ìgbèkùn yín
    padà bọ sípò ní ojú ara yín,”
    ni Olúwa wí.

Jerusalem

Woe to the city of oppressors,(A)
    rebellious(B) and defiled!(C)
She obeys(D) no one,
    she accepts no correction.(E)
She does not trust(F) in the Lord,
    she does not draw near(G) to her God.
Her officials within her
    are roaring lions;(H)
her rulers are evening wolves,(I)
    who leave nothing for the morning.(J)
Her prophets are unprincipled;
    they are treacherous people.(K)
Her priests profane the sanctuary
    and do violence to the law.(L)
The Lord within her is righteous;(M)
    he does no wrong.(N)
Morning by morning(O) he dispenses his justice,
    and every new day he does not fail,(P)
    yet the unrighteous know no shame.(Q)

Jerusalem Remains Unrepentant

“I have destroyed nations;
    their strongholds are demolished.
I have left their streets deserted,
    with no one passing through.
Their cities are laid waste;(R)
    they are deserted and empty.
Of Jerusalem I thought,
    ‘Surely you will fear me
    and accept correction!’(S)
Then her place of refuge[a] would not be destroyed,
    nor all my punishments come upon[b] her.
But they were still eager
    to act corruptly(T) in all they did.
Therefore wait(U) for me,”
    declares the Lord,
    “for the day I will stand up to testify.[c]
I have decided to assemble(V) the nations,(W)
    to gather the kingdoms
and to pour out my wrath(X) on them—
    all my fierce anger.(Y)
The whole world will be consumed(Z)
    by the fire of my jealous anger.

Restoration of Israel’s Remnant

“Then I will purify the lips of the peoples,
    that all of them may call(AA) on the name of the Lord(AB)
    and serve(AC) him shoulder to shoulder.
10 From beyond the rivers of Cush[d](AD)
    my worshipers, my scattered people,
    will bring me offerings.(AE)
11 On that day you, Jerusalem, will not be put to shame(AF)
    for all the wrongs you have done to me,(AG)
because I will remove from you
    your arrogant boasters.(AH)
Never again will you be haughty
    on my holy hill.(AI)
12 But I will leave within you
    the meek(AJ) and humble.
The remnant of Israel
    will trust(AK) in the name of the Lord.
13 They(AL) will do no wrong;(AM)
    they will tell no lies.(AN)
A deceitful tongue
    will not be found in their mouths.(AO)
They will eat and lie down(AP)
    and no one will make them afraid.(AQ)

14 Sing, Daughter Zion;(AR)
    shout aloud,(AS) Israel!
Be glad and rejoice(AT) with all your heart,
    Daughter Jerusalem!
15 The Lord has taken away your punishment,
    he has turned back your enemy.
The Lord, the King of Israel, is with you;(AU)
    never again will you fear(AV) any harm.(AW)
16 On that day
    they will say to Jerusalem,
“Do not fear, Zion;
    do not let your hands hang limp.(AX)
17 The Lord your God is with you,
    the Mighty Warrior who saves.(AY)
He will take great delight(AZ) in you;
    in his love he will no longer rebuke you,(BA)
    but will rejoice over you with singing.”(BB)

18 “I will remove from you
    all who mourn over the loss of your appointed festivals,
    which is a burden and reproach for you.
19 At that time I will deal
    with all who oppressed(BC) you.
I will rescue the lame;
    I will gather the exiles.(BD)
I will give them praise(BE) and honor
    in every land where they have suffered shame.
20 At that time I will gather you;
    at that time I will bring(BF) you home.
I will give you honor(BG) and praise(BH)
    among all the peoples of the earth
when I restore your fortunes[e](BI)
    before your very eyes,”
says the Lord.

Footnotes

  1. Zephaniah 3:7 Or her sanctuary
  2. Zephaniah 3:7 Or all those I appointed over
  3. Zephaniah 3:8 Septuagint and Syriac; Hebrew will rise up to plunder
  4. Zephaniah 3:10 That is, the upper Nile region
  5. Zephaniah 3:20 Or I bring back your captives