Add parallel Print Page Options

Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu.

40 Mo fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ dúró de Olúwa;
    ó sì dẹtí sí mi, ó sì gbọ́ ẹkún mi.
Ó fà mí yọ gòkè
    láti inú ihò ìparun,
láti inú ẹrẹ̀ pọ̀tọ̀pọ́tọ̀,
    ó sì fi ẹsẹ̀ mi lé orí àpáta,
ó sì jẹ́ kí ìgbésẹ̀ mi wà láìfòyà.
Ó fi orin tuntun sí mi lẹ́nu,
    àní orin ìyìn sí Ọlọ́run wa.
Ọ̀pọ̀ yóò rí i wọn yóò sì bẹ̀rù,
    wọn yóò sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa.

Ayọ̀ ni fún àwọn wọ̀n-ọn-nì
    tí ó fi Olúwa ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé wọn
tí wọn kò sì yípadà sí agbéraga,
    tàbí àwọn tí ó yapa
lọ sí ọ̀dọ̀ ọlọ́run mìíràn.
Olúwa Ọlọ́run mi, Ọ̀pọ̀lọpọ̀
    ni àwọn iṣẹ́ ìyanu tí ìwọ ti ṣe.
Àwọn ohun tí ìwọ ti ṣètò sílẹ̀ fún wa;
    ni ẹnikẹ́ni kò le kà wọ́n fún ọ lẹ́sẹẹsẹ
tí èmi yóò sì sọ̀rọ̀ wọn,
    wọ́n ju ohun tí
ènìyàn le è kà lọ.

(A)Ẹbọ àti ẹran ẹbọ ni ìwọ kò fẹ́,
    ìwọ ti ṣí mi ní etí.
Ọrẹ ẹbọ sísun àti ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀
    ni ìwọ kò béèrè.
Nígbà náà ni mo wí pé,
    “Èmi nìyí;
nínú ìwé kíká ni
    a kọ ọ nípa tèmi wí pé.
Mo ní inú dídùn
    láti ṣe ìfẹ́ ẹ̀ rẹ,
ìwọ Ọlọ́run mi;
    Òfin rẹ̀ ń bẹ ní àyà mi.”

Èmi ti sọ ìròyìn ayọ̀ ti ìgbàlà
    láàrín àwùjọ ńlá;
wò ó,
    èmi kò pa ètè mi mọ́,
gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti mọ̀,
    ìwọ Olúwa.
10 Èmi kò fi ìrànlọ́wọ́ ìgbàlà sin ní àyà mi;
    èmí ti sọ̀rọ̀ nípa òtítọ́ àti ìgbàlà rẹ.
Èmi kò sì pa ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti òtítọ́ rẹ̀ mọ́
    kúrò láàrín àwọn ìjọ ńlá.

11 Ìwọ má ṣe,
    fa àánú rẹ tí ó rọ́nú
sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ mi; Olúwa
    jẹ́ kí ìṣeun ìfẹ́ rẹ
àti òtítọ́ rẹ
    kí ó máa pa mi mọ́
títí ayérayé.
12 Nítorí pé àìníye ibi
    ni ó yí mi káàkiri,
ẹ̀ṣẹ̀ mi sì dì mọ́ mi,
    títí tí èmi kò fi ríran mọ́;
wọ́n pọ̀ ju irun orí mi lọ,
    àti wí pé àyà mí ti kùnà.

13 (B)Jẹ́ kí ó wù ọ́,
    ìwọ Olúwa,
láti gbà mí là;
    Olúwa,
yára láti ràn mí lọ́wọ́.

14 Gbogbo àwọn wọ̀n-ọn-nì
    ni kí ojú kí ó tì
kí wọn kí ó sì dààmú
    àwọn tí ń wá ọkàn mi
láti parun:
    jẹ́ kí a lé wọn padà sẹ́yìn
kí a sì dójútì wọ́n,
    àwọn tí ń wá ìpalára mi.
15 Jẹ́ kí àwọn tí ó wí fún mi pé, “Háà! Háà!”
    ó di ẹni à fi ọwọ́ rọ́ sẹ́yìn nítorí ìtìjú wọn.
16 Jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ń wá ọ
    kí ó máa yọ̀
kí inú wọn sì máa dùn sí ọ;
    kí gbogbo àwọn tí ó sì fẹ́ ìgbàlà rẹ
kí o máa wí nígbà gbogbo pé,
    “Gbígbéga ni Olúwa!”

17 Bí ó ṣe ti èmi ni,
    tálákà àti aláìní ni èmi,
ṣùgbọ́n Olúwa ń ṣe ìrántí mi.
    Ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ mi
àti ìgbàlà mi;
    Má ṣe jẹ́ kí ó pẹ́,
    ìwọ Ọlọ́run mi.

Psalm 40[a](A)

For the director of music. Of David. A psalm.

I waited patiently(B) for the Lord;
    he turned to me and heard my cry.(C)
He lifted me out of the slimy pit,(D)
    out of the mud(E) and mire;(F)
he set my feet(G) on a rock(H)
    and gave me a firm place to stand.
He put a new song(I) in my mouth,
    a hymn of praise to our God.
Many will see and fear the Lord(J)
    and put their trust(K) in him.

Blessed is the one(L)
    who trusts in the Lord,(M)
who does not look to the proud,(N)
    to those who turn aside to false gods.[b](O)
Many, Lord my God,
    are the wonders(P) you have done,
    the things you planned for us.
None can compare(Q) with you;
    were I to speak and tell of your deeds,
    they would be too many(R) to declare.

Sacrifice and offering you did not desire—(S)
    but my ears you have opened[c](T)
    burnt offerings(U) and sin offerings[d] you did not require.
Then I said, “Here I am, I have come—
    it is written about me in the scroll.[e](V)
I desire to do your will,(W) my God;(X)
    your law is within my heart.”(Y)

I proclaim your saving acts(Z) in the great assembly;(AA)
    I do not seal my lips, Lord,
    as you know.(AB)
10 I do not hide your righteousness in my heart;
    I speak of your faithfulness(AC) and your saving help.
I do not conceal your love and your faithfulness
    from the great assembly.(AD)

11 Do not withhold your mercy(AE) from me, Lord;
    may your love(AF) and faithfulness(AG) always protect(AH) me.
12 For troubles(AI) without number surround me;
    my sins have overtaken me, and I cannot see.(AJ)
They are more than the hairs of my head,(AK)
    and my heart fails(AL) within me.
13 Be pleased to save me, Lord;
    come quickly, Lord, to help me.(AM)

14 May all who want to take my life(AN)
    be put to shame and confusion;(AO)
may all who desire my ruin(AP)
    be turned back in disgrace.
15 May those who say to me, “Aha! Aha!”(AQ)
    be appalled at their own shame.
16 But may all who seek you(AR)
    rejoice and be glad(AS) in you;
may those who long for your saving help always say,
    “The Lord is great!”(AT)

17 But as for me, I am poor and needy;(AU)
    may the Lord think(AV) of me.
You are my help(AW) and my deliverer;(AX)
    you are my God, do not delay.(AY)

Footnotes

  1. Psalm 40:1 In Hebrew texts 40:1-17 is numbered 40:2-18.
  2. Psalm 40:4 Or to lies
  3. Psalm 40:6 Hebrew; some Septuagint manuscripts but a body you have prepared for me
  4. Psalm 40:6 Or purification offerings
  5. Psalm 40:7 Or come / with the scroll written for me