Add parallel Print Page Options

119 Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ọ̀nà wọn wà láìlẹ́ṣẹ̀,
    ẹni tí í rìn ní ìbámu pẹ̀lú òfin Olúwa,
Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ń pa òfin rẹ̀ mọ́
    tí wọn sì ń wá a pẹ̀lú gbogbo ọkàn wọn.
Wọn kò ṣe ohun tí kò dára;
    wọ́n rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
Ìwọ ti la ìlànà rẹ̀ sílẹ̀
    kí a sì pa wọ́n mọ́ gidigidi.
Ọ̀nà mi ìbá dúró ṣinṣin
    láti máa pa òfin rẹ̀ mọ́!
Nígbà náà, ojú kò ní tì mí
    nígbà tí mo bá ń kíyèsi àṣẹ rẹ̀ gbogbo.
Èmi yóò yìn ọ́ pẹ̀lú ọkàn ìdúró ṣinṣin
    bí èmi bá ti kọ́ òfin òdodo rẹ̀.
Èmi yóò gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀:
    Má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ pátápátá.

Báwo ni àwọn ọ̀dọ́ yóò ti ṣe pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́?
Láti máa gbé ní ìbámu sí ọ̀rọ̀ rẹ.
10 Èmi wá ọ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi
    má ṣe jẹ́ kí èmi yapa kúrò nínú àṣẹ rẹ.
11 Èmi ti pa ọ̀rọ̀ rẹ mọ́ ní ọkàn mi
    kí èmi má ba à ṣẹ̀ sí ọ
12 Ìyìn ni fún Olúwa;
    kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
13 Pẹ̀lú ètè mi èmi tún ṣírò
    gbogbo òfin tí ó wá láti ẹnu rẹ.
14 Èmi ń yọ̀ ní ọ̀nà ẹ̀rí rẹ,
    bí ènìyàn ṣe ń yọ̀ nínú ọláńlá.
15 Èmi ń ṣe àṣàrò nínú ìlànà rẹ
    èmi sì kíyèsi ọ̀nà rẹ
16 Inú mi dùn sí àṣẹ rẹ;
    èmi kì yóò gbàgbé ọ̀nà rẹ.

Ohun ìyanu tí o wà nínú òfin rẹ̀

17 Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ, èmi yóò sì wà láààyè;
    èmi yóò ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ rẹ.
18 La ojú mi kí èmi lè ríran rí
    ohun ìyanu tí ó wà nínú òfin rẹ.
19 Àlejò ní èmi jẹ́ láyé;
    Má ṣe pa àṣẹ rẹ mọ́ fún mi.
20 Ọkàn mi pòruurù pẹ̀lú ìfojúsọ́nà
    nítorí òfin rẹ nígbà gbogbo.
21 Ìwọ fi àwọn agbéraga bú, àwọn tí a fi gégùn ún
    tí ó ṣìnà kúrò nínú àṣẹ rẹ.
22 Mú ẹ̀gàn àti àbùkù kúrò lára mi,
    nítorí èmi pa òfin rẹ mọ́.
23 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn alákòóso kójọpọ̀, wọ́n
    ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí mi,
    ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ ń ṣe àṣàrò nínú àṣẹ rẹ.
24 Òfin rẹ ni dídùn inú mi;
    àwọn ní olùbádámọ̀ràn mi.

Àdúrà láti ní òye ọ̀rọ̀ Ọlọ́run

25 Ọkàn mí lẹ̀ mọ́ erùpẹ̀;
    ìwọ sọ mí di ààyè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
26 Èmi tún ọ̀nà mi ṣírò ìwọ sì dá mi lóhùn;
    kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
27 Jẹ́ kí n mọ ẹ̀kọ́ ìlànà rẹ:
    nígbà náà ni èmi yóò ṣe àṣàrò iṣẹ́ ìyanu rẹ.
28 Ọkàn mi ń ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú ìbànújẹ́;
    fi agbára fún mi gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
29 Pa mí mọ́ kúrò nínú ọ̀nà ẹ̀tàn
    fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ nípa òfin rẹ.
30 Èmi ti yan ọ̀nà òtítọ́
    èmi ti gbé ọkàn mi lé òfin rẹ.
31 Èmi yára di òfin rẹ mú. Olúwa
    má ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí.
32 Èmi sáré ní ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ,
    nítorí ìwọ, ti tú ọkàn mi sílẹ̀.

Ìlérí Ọlọ́run fún aláforítì

33 Kọ́ mi, Olúwa, láti tẹ̀lé àṣẹ rẹ;
    nígbà náà ni èmi yóò pa wọ́n mọ́ dé òpin.
34 Fún mi ní òye, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́
    èmi yóò sì máa kíyèsi i pẹ̀lú ọkàn mi.
35 Fi ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ hàn mí,
    nítorí nínú rẹ̀ ni èmi rí inú dídùn.
36 Yí ọkàn mi padà sí òfin rẹ
    kí ó má ṣe sí ojúkòkòrò mọ́.
37 Yí ojú mi padà kúrò láti máa wo ohun asán:
    pa ọ̀nà mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
38 Mú ìlérí rẹ sẹ sí ìránṣẹ́ rẹ,
    nítorí òfin rẹ dára.
39 Yí ẹ̀gàn mi padà tí mo bẹ̀rù
    nítorí tí ìdájọ́ rẹ dára.
40 Kíyèsi i, ọkàn mi ti fà sí ẹ̀kọ́ rẹ!
    Pa ayé mi mọ́ nínú òdodo rẹ.

Ìgbàlà láti inú òfin Ọlọ́run

41 Jẹ́ kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà wá bá mi, Olúwa,
    ìgbàlà rẹ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ;
42 Nígbà náà ni èmi yóò dá
    ẹni tí ń sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí mi lóhùn,
    nítorí èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ.
43 Má ṣe gba ọ̀rọ̀ òtítọ́ láti ẹnu mi
    nítorí èmi ti gbé ìrètí mi sínú àṣẹ rẹ
44 Èmi yóò máa gbọ́rọ̀ sí òfin rẹ nígbà gbogbo
    láé àti láéláé.
45 Èmi yóò máa rìn káàkiri ní òmìnira,
    nítorí èmi ti kígbe ẹ̀kọ́ rẹ jáde.
46 Èmi yóò sọ̀rọ̀ òfin rẹ níwájú àwọn ọba
    ojú kì yóò sì tì mí,
47 Nítorí èmi ní inú dídùn nínú àṣẹ rẹ
    nítorí èmi ní ìfẹ́ wọn.
48 Èmi gbé ọwọ́ mi sókè nítorí àṣẹ rẹ, èyí tí èmi fẹ́ràn,
    èmi sì ń ṣe àṣàrò òfin rẹ̀.

Òfin Ọlọ́run ní ìrètí

49 Rántí ọ̀rọ̀ rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ,
    nítorí ìwọ ti fún mi ní ìrètí.
50 Ìtùnú mi nínú ìpọ́njú mi ni èyí:
    ìpinnu rẹ pa ayé mi mọ́.
51 Àwọn agbéraga fi mí ṣe ẹlẹ́yà láì dádúró,
    ṣùgbọ́n èmi kò padà nínú òfin rẹ.
52 Èmi rántí àwọn òfin rẹ ìgbàanì, Olúwa,
    èmi sì rí ìtùnú nínú wọn.
53 Ìbínú dì mímú ṣinṣin nítorí àwọn ẹni búburú,
    tí wọ́n ti kọ òfin rẹ sílẹ̀.
54 Òfin rẹ ni ọ̀rọ̀ ìpìlẹ̀ orin mi
    níbikíbi tí èmi ń gbé.
55 Ní òru èmi rántí orúkọ rẹ, Olúwa,
    èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́
56 nítorí tí mo
    gba ẹ̀kọ́ rẹ gbọ́.

Ọlọ́run ni ìpín wa

57 Ìwọ ni ìpín mi, Olúwa:
    èmi ti pinnu láti tẹríba sí ọ̀rọ̀ rẹ.
58 Èmi ti wá ojú rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi:
    fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
59 Èmi ti kíyèsi ọ̀nà mi
    èmi sì ti gbé ìgbésẹ̀ mi sí òfin rẹ.
60 Èmi yóò yára, ń kò ni lọ́ra
    láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
61 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ẹni búburú dì mí pẹ̀lú okùn,
    èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
62 Ní àárín ọ̀gànjọ́ òru èmi dìde láti fi ọpẹ́ fún ọ
    nítorí òfin òdodo rẹ.
63 Èmi jẹ́ ọ̀rẹ́ sí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ,
    sí gbogbo àwọn tí ń tẹ̀lé ẹ̀kọ́ rẹ.
64 Ayé kún fún ìfẹ́ rẹ Olúwa
    Kọ́ mi ní òfin rẹ.

Ìpọ́njú mu ni mọ òfin Ọlọ́run

65 Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ
    gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa.
66 Kọ́ mi ní ìmọ̀ àti ìdájọ́ rere,
    nítorí mo gbàgbọ́ nínú àṣẹ rẹ.
67 Kí a tó pọ́n mi lójú èmi ti ṣìnà,
    ṣùgbọ́n ni ìsinsin yìí èmi gbọ́rọ̀ sí ọ̀rọ̀ rẹ.
68 Ìwọ dára, ohun tí ìwọ sì ń ṣe rere ni;
    kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
69 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn agbéraga ti gbìmọ̀ èké sí mí,
    èmi pa ẹ̀kọ́ rẹ mọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi.
70 Ọkàn wọn yigbì kò sì ní àánú,
    ṣùgbọ́n èmi ní inú dídùn nínú òfin rẹ.
71 Ó dára fún mi kí a pọ́n mi lójú
    nítorí kí èmi lè kọ́ òfin rẹ.
72 Òfin tí ó jáde láti ẹnu rẹ ju iyebíye sí mi lọ
    ó ju ẹgbẹ̀rún ẹyọ fàdákà àti wúrà lọ.

Ẹlẹgbẹ́ mi ni àwọn tó mọ òfin Olúwa

73 Ọwọ́ rẹ ni ó dá mi tí ó sì mọ mí;
    fún mi ní òye láti kọ́ àṣẹ rẹ.
74 Jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ máa yọ̀ nígbà tí wọ́n bá rí mi,
    nítorí èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
75 Èmi mọ, Olúwa, nítorí òfin rẹ òdodo ni,
    àti ní òtítọ́ ni ìwọ pọ́n mi lójú.
76 Kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà jẹ́ ìtùnú mi,
    gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ.
77 Jẹ́ kí àánú rẹ kí ó tọ̀ mí wá, kí èmi kí ó lè yè,
    nítorí òfin rẹ jẹ́ ìdùnnú mi.
78 Kí ojú kí ó ti àwọn agbéraga
    nítorí wọn pa mí lára láìnídìí
    ṣùgbọ́n èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
79 Kí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ yí padà sí mi,
    àwọn tí ó ní òye òfin rẹ.
80 Jẹ́ kí ọkàn mi wà láìlẹ́bi sí òfin rẹ,
    kí ojú kí ó má ṣe tì mí.

Wíwá àlàáfíà

81 Ọkàn mi ń fojú ṣọ́nà nítorí ìgbàlà rẹ,
    ṣùgbọ́n èmi ti fi ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
82 Ojú mi kùnà, pẹ̀lú wíwo ìpinnu rẹ;
    èmi wí pé, “Nígbà wo ni ìwọ yóò tù mí nínú?”
83 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi dàbí awọ-wáìnì lójú èéfín,
    èmi kò gbàgbé ìlànà rẹ.
84 Báwo ni ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò ṣe dúró pẹ́ tó?
    Nígbà wo ni ìwọ yóò bá àwọn
    tí ń ṣe inúnibíni sí mi wí?
85 Àwọn agbéraga wa ihò ìṣubú fún mi,
    tí ó lòdì sí òfin rẹ.
86 Gbogbo àṣẹ rẹ yẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé:
    ràn mí lọ́wọ́, nítorí ènìyàn
    ń ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí.
87 Wọ́n fẹ́rẹ pa mí rẹ́ kúrò nínú ayé,
    ṣùgbọ́n èmi kò kọ ẹ̀kọ́ rẹ.
88 Pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ,
    èmi yóò sì gba ẹ̀rí ẹnu rẹ̀ gbọ́.

Ọ̀rọ̀ Olúwa dúró títí láé

89 Ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa, títí láé ni;
    ó dúró ṣinṣin ní ọ̀run
90 Òtítọ́ rẹ̀ ń lọ dé gbogbo ìran dé ìran;
    ìwọ ti dá ayé, ó sì dúró ṣinṣin.
91 Òfin rẹ dúró di òní
    nítorí ohun gbogbo ń sìn ọ́.
92 Bí òfin rẹ̀ kò bá jẹ́ dídùn inú mi,
    èmi ìbá ti ṣègbé nínú ìpọ́njú mi.
93 Èmi kì yóò gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ láé,
    nítorí nípa wọn ni ìwọ ti pa ayé mi mọ́
94 Gbà mí, nítorí èmi jẹ́ tìrẹ
    èmi ti wá ẹ̀kọ́ rẹ.
95 Àwọn ẹni búburú dúró láti pa mí run,
    ṣùgbọ́n èmi yóò kíyèsi ẹ̀rí rẹ.
96 Sí ohun pípé gbogbo èmi ti rí òpin;
    ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ aláìlópin ni.

Òfin Olúwa ni ìfẹ́ pípé

97 Báwo ni èmi ti fẹ́ òfin rẹ tó!
    Èmi ń ṣe àṣàrò nínú rẹ̀
ní gbogbo ọjọ́ pípẹ́ wá.
98 Àṣẹ rẹ mú mi gbọ́n ju àwọn ọ̀tá mi lọ,
    nítorí wọ́n wà pẹ̀lú mi láé.
99 Èmi ní iyè inú ju gbogbo olùkọ́ mi lọ,
    nítorí èmi ń ṣe àṣàrò nínú òfin rẹ.
100 Èmi ni òye ju àwọn àgbà lọ,
    nítorí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ.
101 Èmi ti pa ẹsẹ̀ mi mọ́ nínú gbogbo ọ̀nà ibi
    nítorí kí èmi lè gba ọ̀rọ̀ rẹ.
102 Èmi kò yà kúrò nínú òfin rẹ,
    nítorí ìwọ fúnrarẹ̀ ni ó kọ́ mi.
103 Báwo ni ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣe dùn mọ́ mi lẹ́nu tó,
    ó dùn ju oyin lọ ní ẹnu mi!
104 Èmi rí òye gbà nínú ẹ̀kọ́ rẹ;
    nítorí náà èmi kórìíra gbogbo ọ̀nà tí kò tọ́.

Òfin Olúwa ni fìtílà mi

105 Ọ̀rọ̀ rẹ ni fìtílà sí ẹsẹ̀ mi
    àti ìmọ́lẹ̀ sí ipa ọ̀nà mi
106 Èmi ti ṣe ìbúra èmi sì ti tẹnumọ́ ọn
    wí pé èmi yóò máa tẹ̀lé òfin òdodo rẹ.
107 A pọ́n mi lójú gidigidi;
    Olúwa, sọ mi di ààyè, gẹ́gẹ́ bi ọ̀rọ̀ rẹ
108 Olúwa, gba ìyìn àtinúwá ẹnu mi,
    kí o sì kọ́ mi ní òfin rẹ̀.
109 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ayé mi wà ni ọwọ́ mi
    nígbà gbogbo,
    èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
110 Àwọn ẹni búburú ti dẹ okùn sílẹ̀ fún mi,
    ṣùgbọ́n èmi kò ṣìnà kúrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
111 Òfin rẹ ni ogún mi láéláé;
    àwọn ni ayọ̀ ọkàn mi.
112 Ọkàn mi ti lé pípa òfin rẹ mọ́
    láé dé òpin.

Òfin Olúwa ni Ààbò mi

113 Èmi kórìíra àwọn ọlọ́kàn méjì,
    ṣùgbọ́n èmi fẹ́ òfin rẹ.
114 Ìwọ ni ààbò mi àti asà mi;
    èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
115 Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi, ẹ̀yin olùṣe búburú,
    kí èmi lè pa àṣẹ Ọlọ́run mi mọ́!
116 Gbé mi sókè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ,
    kí èmi kí ó lè yè
    Má sì jẹ́ kí ojú ìrètí mi kí ó tì mí.
117 Gbé mi sókè, èmí yóò sì wa láìléwu;
    nígbà gbogbo ni èmi yóò máa júbà òfin rẹ.
118 Ìwọ kọ gbogbo àwọn tí ó ṣìnà kúrò nínú òfin rẹ,
    nítorí ẹ̀tàn wọn asán ni.
119 Gbogbo àwọn ẹni búburú ní ayé ni ìwọ yọ kúrò bí i ìdàrọ́;
    nítorí náà, èmi fẹ́ òfin rẹ̀.
120 Ara mi wárìrì ní ìbẹ̀rù nítorí rẹ̀:
    èmi dúró ní ìbẹ̀rù òfin rẹ.

Olórin pa òfin Olúwa mọ́

121 Èmi ti ṣe ohun tí i ṣe òdodo àti ẹ̀tọ́:
    má ṣe fi mí sílẹ̀ fún àwọn tó ń ni mí lára.
122 Mú kí àlàáfíà ìránṣẹ́ rẹ dájú:
    má ṣe jẹ́ kí àwọn agbéraga ni mi lára.
123 Ojú mi kùnà, fún wíwo ìgbàlà rẹ,
    fún wíwo ìpinnu òdodo rẹ.
124 Ṣe pẹ̀lú ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí dídúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ
    kí o sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
125 Èmi ni ìránṣẹ́ rẹ; ẹ fún mi ní òye
    kí èmi lè ní òye òfin rẹ
126 Ó tó àsìkò fún ọ láti ṣe iṣẹ́, Olúwa;
    nítorí òfin rẹ ti fọ́.
127 Nítorí èmi fẹ́ràn àṣẹ rẹ
    ju wúrà, àní ju wúrà dídára lọ,
128 Nítorí èmi kíyèsi gbogbo ẹ̀kọ́ òtítọ́ rẹ̀,
    èmi kórìíra gbogbo ipa ọ̀nà búburú.

Àdúrà láti lè pa òfin Olúwa mọ́

129 Òfin rẹ̀ ìyanu ni:
    nítorí náà èmi gbà wọ́n gbọ́.
130 Ìṣípayá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú ìmọ́lẹ̀ wá;
    ó fi òye fún àwọn òpè.
131 Èmi ya ẹnu mi mo sì mí hẹlẹ,
    nítorí èmi fojú ṣọ́nà sí àṣẹ rẹ.
132 Yí padà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi,
    bí ìwọ ṣe máa ń ṣe nígbà gbogbo sí àwọn
    tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ.
133 Fi ìṣísẹ̀ mi múlẹ̀ nínú ọ̀rọ̀ rẹ,
    má ṣe jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ borí mi.
134 Rà mí padà lọ́wọ́ aninilára ènìyàn,
    kí èmi lè gbọ́ ẹ̀kọ́ rẹ.
135 Jẹ́ kí ojú rẹ kí ó tàn sí ìránṣẹ́ rẹ lára
    kí ó sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
136 Omijé sàn jáde ní ojú mi,
    nítorí wọn kò gba pé òfin rẹ̀ jẹ́ òtítọ́.
137 Olódodo ni ìwọ Olúwa
    ìdájọ́ rẹ sì dúró ṣinṣin
138 Òfin ti ìwọ gbé kalẹ̀ jẹ́ òdodo:
    wọ́n yẹ ni ìgbẹ́kẹ̀lé.
139 Ìtara mi ti pa mí run,
    nítorí àwọn ọ̀tá mi fi ojú fo ọ̀rọ̀ rẹ dá.
140 Wọ́n ti dán ìpinnu rẹ wò pátápátá
    ìránṣẹ́ rẹ sì fẹ́ràn wọ́n.
141 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ àti ẹni ẹ̀gàn
    èmi kò ni gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ.
142 Òdodo rẹ wà títí láé
    òtítọ́ ni òfin rẹ̀.
143 Ìyọnu àti ìpọ́njú wá sórí mi,
    ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ ni inú dídùn mi,
144 Òfin rẹ jẹ́ òtítọ́ láé;
    fún mi ní òye kí èmi lè yè.

Kíkígbe fún ìgbàlà

145 Èmi kígbe pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi:
    dá mi lóhùn Olúwa,
    èmi yóò sì gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
146 Èmi kígbe pè ọ́; gbà mí
    èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́.
147 Èmi dìde ṣáájú àfẹ̀mọ́júmọ́ èmi ké fún ìrànlọ́wọ́;
    èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
148 Ojú mi ṣáájú ìṣọ́ òru,
    nítorí kí èmi lè ṣe àṣàrò nínú ọ̀rọ̀ rẹ.
149 Gbọ́ ohùn mi ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú ìfẹ́ rẹ:
    pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
150 Àwọn tí ń gbìmọ̀ ìlànà búburú wà ní tòsí,
    ṣùgbọ́n wọ́n jìnnà sí òfin rẹ.
151 Síbẹ̀ ìwọ wà ní tòsí, Olúwa,
    àti gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òtítọ́.
152 Láti ọjọ́ pípẹ́ wá èmi ti kọ́ nínú òfin rẹ
    tí ìwọ ti fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé.

Pípa òfin mọ́ ni ìpọ́njú

153 Wo ìpọ́njú mi kí o sì gbà mí,
    nítorí èmi kò gbàgbé òfin rẹ.
154 Gba ẹjọ́ mi rò kí o sì rà mí padà;
    pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
155 Ìgbàlà jìnnà sí àwọn ẹni búburú
    nítorí wọn kò wá àṣẹ rẹ.
156 Ìyọ́nú rẹ̀ tóbi, Olúwa;
    pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
157 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn ọ̀tá tí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí mi,
    ṣùgbọ́n èmi kò tí ì yípadà kúrò nínú òfin rẹ.
158 Èmi wo àwọn ẹlẹ́tàn, inú mi sì bàjẹ́
    nítorí wọn kò gba ọ̀rọ̀ rẹ gbọ́.
159 Wo bí èmi ṣe fẹ́ràn ẹ̀kọ́ rẹ;
    pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ.
160 Òtítọ́ ni gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ;
    gbogbo òfin òdodo rẹ láéláé ni.
161 Àwọn alákòóso ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí,
    ṣùgbọ́n ọkàn mi wárìrì sí ọ̀rọ̀ rẹ.
162 Èmi yọ̀ nínú ìpinnu rẹ
    bí ẹni tí ó rí ìkógun púpọ̀.
163 Èmi kórìíra mo sì kọ èké ṣíṣe
    ṣùgbọ́n mo fẹ́ràn òfin rẹ.
164 Èmi yìn ọ́ ní ìgbà méje lójúmọ́
    nítorí òfin òdodo rẹ.
165 Àlàáfíà púpọ̀ wà fún àwọn tí ó ní ìfẹ́ sí òfin rẹ,
    kò sì ṣí ohun tí ó lè mú wọn kọsẹ̀.
166 Èmi yóò dúró de ìgbàlà rẹ, Olúwa,
    èmi yóò sì tẹ̀lé àṣẹ rẹ.
167 Èmi gba òfin rẹ gbọ́,
    nítorí mo fẹ́ràn wọn púpọ̀púpọ̀
168 Èmi ṣe ìgbọ́ràn sí ẹ̀kọ́ rẹ àti òfin rẹ,
    nítorí ìwọ mọ gbogbo ọ̀nà mi.
169 Jẹ́ kí igbe mi wá sí iwájú rẹ, Olúwa;
    fún mi ní òye gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
170 Jẹ́ kí ẹ̀bẹ̀ mi wá sí iwájú rẹ;
    gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
171 Ètè mi yóò sọ ìyìn jáde,
    nítorí ìwọ kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
172 Jẹ́ kí ahọ́n mi kọ orin ọ̀rọ̀ rẹ,
    nítorí gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òdodo.
173 Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ ṣetán láti ràn mí lọ́wọ́,
    nítorí èmi ti yan ẹ̀kọ́ rẹ.
174 Èmi wo ọ̀nà fún ìgbàlà rẹ, Olúwa,
    àti òfin rẹ jẹ́ dídùn inú mi.
175 Jẹ́ kí èmi wà láààyè ki èmi lè yìn ọ́,
    kí o sì jẹ́ kí òfin rẹ mú mi dúró.
176 Èmí ti ṣìnà bí àgùntàn tí ó
    sọnù, wá ìránṣẹ́ rẹ,
    nítorí èmi kò gbàgbé àṣẹ rẹ.

Psalm 119[a]

א Aleph

Blessed are those whose ways are blameless,(A)
    who walk(B) according to the law of the Lord.(C)
Blessed(D) are those who keep his statutes(E)
    and seek him(F) with all their heart—(G)
they do no wrong(H)
    but follow his ways.(I)
You have laid down precepts(J)
    that are to be fully obeyed.(K)
Oh, that my ways were steadfast
    in obeying your decrees!(L)
Then I would not be put to shame(M)
    when I consider all your commands.(N)
I will praise you with an upright heart
    as I learn your righteous laws.(O)
I will obey your decrees;
    do not utterly forsake me.(P)

ב Beth

How can a young person stay on the path of purity?(Q)
    By living according to your word.(R)
10 I seek you with all my heart;(S)
    do not let me stray from your commands.(T)
11 I have hidden your word in my heart(U)
    that I might not sin(V) against you.
12 Praise be(W) to you, Lord;
    teach me(X) your decrees.(Y)
13 With my lips I recount
    all the laws that come from your mouth.(Z)
14 I rejoice in following your statutes(AA)
    as one rejoices in great riches.
15 I meditate on your precepts(AB)
    and consider your ways.
16 I delight(AC) in your decrees;
    I will not neglect your word.

ג Gimel

17 Be good to your servant(AD) while I live,
    that I may obey your word.(AE)
18 Open my eyes that I may see
    wonderful things in your law.
19 I am a stranger on earth;(AF)
    do not hide your commands from me.
20 My soul is consumed(AG) with longing
    for your laws(AH) at all times.
21 You rebuke the arrogant,(AI) who are accursed,(AJ)
    those who stray(AK) from your commands.
22 Remove from me their scorn(AL) and contempt,
    for I keep your statutes.(AM)
23 Though rulers sit together and slander me,
    your servant will meditate on your decrees.
24 Your statutes are my delight;
    they are my counselors.

ד Daleth

25 I am laid low in the dust;(AN)
    preserve my life(AO) according to your word.(AP)
26 I gave an account of my ways and you answered me;
    teach me your decrees.(AQ)
27 Cause me to understand the way of your precepts,
    that I may meditate on your wonderful deeds.(AR)
28 My soul is weary with sorrow;(AS)
    strengthen me(AT) according to your word.(AU)
29 Keep me from deceitful ways;(AV)
    be gracious to me(AW) and teach me your law.
30 I have chosen(AX) the way of faithfulness;(AY)
    I have set my heart(AZ) on your laws.
31 I hold fast(BA) to your statutes, Lord;
    do not let me be put to shame.
32 I run in the path of your commands,
    for you have broadened my understanding.

ה He

33 Teach me,(BB) Lord, the way of your decrees,
    that I may follow it to the end.[b]
34 Give me understanding,(BC) so that I may keep your law(BD)
    and obey it with all my heart.(BE)
35 Direct me(BF) in the path of your commands,(BG)
    for there I find delight.(BH)
36 Turn my heart(BI) toward your statutes
    and not toward selfish gain.(BJ)
37 Turn my eyes away from worthless things;
    preserve my life(BK) according to your word.[c](BL)
38 Fulfill your promise(BM) to your servant,
    so that you may be feared.
39 Take away the disgrace(BN) I dread,
    for your laws are good.
40 How I long(BO) for your precepts!
    In your righteousness preserve my life.(BP)

ו Waw

41 May your unfailing love(BQ) come to me, Lord,
    your salvation, according to your promise;(BR)
42 then I can answer(BS) anyone who taunts me,(BT)
    for I trust in your word.
43 Never take your word of truth from my mouth,(BU)
    for I have put my hope(BV) in your laws.
44 I will always obey your law,(BW)
    for ever and ever.
45 I will walk about in freedom,
    for I have sought out your precepts.(BX)
46 I will speak of your statutes before kings(BY)
    and will not be put to shame,(BZ)
47 for I delight(CA) in your commands
    because I love them.(CB)
48 I reach out for your commands, which I love,
    that I may meditate(CC) on your decrees.

ז Zayin

49 Remember your word(CD) to your servant,
    for you have given me hope.(CE)
50 My comfort in my suffering is this:
    Your promise preserves my life.(CF)
51 The arrogant mock me(CG) unmercifully,
    but I do not turn(CH) from your law.
52 I remember,(CI) Lord, your ancient laws,
    and I find comfort in them.
53 Indignation grips me(CJ) because of the wicked,
    who have forsaken your law.(CK)
54 Your decrees are the theme of my song(CL)
    wherever I lodge.
55 In the night, Lord, I remember(CM) your name,
    that I may keep your law.(CN)
56 This has been my practice:
    I obey your precepts.(CO)

ח Heth

57 You are my portion,(CP) Lord;
    I have promised to obey your words.(CQ)
58 I have sought(CR) your face with all my heart;
    be gracious to me(CS) according to your promise.(CT)
59 I have considered my ways(CU)
    and have turned my steps to your statutes.
60 I will hasten and not delay
    to obey your commands.(CV)
61 Though the wicked bind me with ropes,
    I will not forget(CW) your law.
62 At midnight(CX) I rise to give you thanks
    for your righteous laws.(CY)
63 I am a friend to all who fear you,(CZ)
    to all who follow your precepts.(DA)
64 The earth is filled with your love,(DB) Lord;
    teach me your decrees.(DC)

ט Teth

65 Do good(DD) to your servant
    according to your word,(DE) Lord.
66 Teach me knowledge(DF) and good judgment,
    for I trust your commands.
67 Before I was afflicted(DG) I went astray,(DH)
    but now I obey your word.(DI)
68 You are good,(DJ) and what you do is good;
    teach me your decrees.(DK)
69 Though the arrogant have smeared me with lies,(DL)
    I keep your precepts with all my heart.
70 Their hearts are callous(DM) and unfeeling,
    but I delight in your law.
71 It was good for me to be afflicted(DN)
    so that I might learn your decrees.
72 The law from your mouth is more precious to me
    than thousands of pieces of silver and gold.(DO)

י Yodh

73 Your hands made me(DP) and formed me;
    give me understanding to learn your commands.
74 May those who fear you rejoice(DQ) when they see me,
    for I have put my hope in your word.(DR)
75 I know, Lord, that your laws are righteous,(DS)
    and that in faithfulness(DT) you have afflicted me.
76 May your unfailing love(DU) be my comfort,
    according to your promise(DV) to your servant.
77 Let your compassion(DW) come to me that I may live,
    for your law is my delight.(DX)
78 May the arrogant(DY) be put to shame for wronging me without cause;(DZ)
    but I will meditate on your precepts.
79 May those who fear you turn to me,
    those who understand your statutes.(EA)
80 May I wholeheartedly follow(EB) your decrees,(EC)
    that I may not be put to shame.(ED)

כ Kaph

81 My soul faints(EE) with longing for your salvation,(EF)
    but I have put my hope(EG) in your word.
82 My eyes fail,(EH) looking for your promise;(EI)
    I say, “When will you comfort me?”
83 Though I am like a wineskin in the smoke,
    I do not forget(EJ) your decrees.
84 How long(EK) must your servant wait?
    When will you punish my persecutors?(EL)
85 The arrogant(EM) dig pits(EN) to trap me,
    contrary to your law.
86 All your commands are trustworthy;(EO)
    help me,(EP) for I am being persecuted(EQ) without cause.(ER)
87 They almost wiped me from the earth,
    but I have not forsaken(ES) your precepts.
88 In your unfailing love(ET) preserve my life,(EU)
    that I may obey the statutes(EV) of your mouth.

ל Lamedh

89 Your word, Lord, is eternal;(EW)
    it stands firm in the heavens.
90 Your faithfulness(EX) continues through all generations;(EY)
    you established the earth, and it endures.(EZ)
91 Your laws endure(FA) to this day,
    for all things serve you.(FB)
92 If your law had not been my delight,(FC)
    I would have perished in my affliction.(FD)
93 I will never forget(FE) your precepts,
    for by them you have preserved my life.(FF)
94 Save me,(FG) for I am yours;
    I have sought out your precepts.(FH)
95 The wicked are waiting to destroy me,(FI)
    but I will ponder your statutes.(FJ)
96 To all perfection I see a limit,
    but your commands are boundless.(FK)

מ Mem

97 Oh, how I love your law!(FL)
    I meditate(FM) on it all day long.
98 Your commands are always with me
    and make me wiser(FN) than my enemies.
99 I have more insight than all my teachers,
    for I meditate on your statutes.(FO)
100 I have more understanding than the elders,
    for I obey your precepts.(FP)
101 I have kept my feet(FQ) from every evil path
    so that I might obey your word.(FR)
102 I have not departed from your laws,(FS)
    for you yourself have taught(FT) me.
103 How sweet are your words to my taste,
    sweeter than honey(FU) to my mouth!(FV)
104 I gain understanding(FW) from your precepts;
    therefore I hate every wrong path.(FX)

נ Nun

105 Your word is a lamp(FY) for my feet,
    a light(FZ) on my path.
106 I have taken an oath(GA) and confirmed it,
    that I will follow your righteous laws.(GB)
107 I have suffered much;
    preserve my life,(GC) Lord, according to your word.
108 Accept, Lord, the willing praise of my mouth,(GD)
    and teach me your laws.(GE)
109 Though I constantly take my life in my hands,(GF)
    I will not forget(GG) your law.
110 The wicked have set a snare(GH) for me,
    but I have not strayed(GI) from your precepts.
111 Your statutes are my heritage forever;
    they are the joy of my heart.(GJ)
112 My heart is set(GK) on keeping your decrees
    to the very end.[d](GL)

ס Samekh

113 I hate double-minded people,(GM)
    but I love your law.(GN)
114 You are my refuge and my shield;(GO)
    I have put my hope(GP) in your word.
115 Away from me,(GQ) you evildoers,
    that I may keep the commands of my God!
116 Sustain me,(GR) my God, according to your promise,(GS) and I will live;
    do not let my hopes be dashed.(GT)
117 Uphold me,(GU) and I will be delivered;(GV)
    I will always have regard for your decrees.(GW)
118 You reject all who stray(GX) from your decrees,
    for their delusions come to nothing.
119 All the wicked of the earth you discard like dross;(GY)
    therefore I love your statutes.(GZ)
120 My flesh trembles(HA) in fear of you;(HB)
    I stand in awe(HC) of your laws.

ע Ayin

121 I have done what is righteous and just;(HD)
    do not leave me to my oppressors.
122 Ensure your servant’s well-being;(HE)
    do not let the arrogant oppress me.(HF)
123 My eyes fail,(HG) looking for your salvation,(HH)
    looking for your righteous promise.(HI)
124 Deal with your servant according to your love(HJ)
    and teach me your decrees.(HK)
125 I am your servant;(HL) give me discernment
    that I may understand your statutes.(HM)
126 It is time for you to act, Lord;
    your law is being broken.(HN)
127 Because I love your commands(HO)
    more than gold,(HP) more than pure gold,(HQ)
128 and because I consider all your precepts right,(HR)
    I hate every wrong path.(HS)

פ Pe

129 Your statutes are wonderful;(HT)
    therefore I obey them.(HU)
130 The unfolding of your words gives light;(HV)
    it gives understanding to the simple.(HW)
131 I open my mouth and pant,(HX)
    longing for your commands.(HY)
132 Turn to me(HZ) and have mercy(IA) on me,
    as you always do to those who love your name.(IB)
133 Direct my footsteps according to your word;(IC)
    let no sin rule(ID) over me.
134 Redeem me from human oppression,(IE)
    that I may obey your precepts.(IF)
135 Make your face shine(IG) on your servant
    and teach me your decrees.(IH)
136 Streams of tears(II) flow from my eyes,
    for your law is not obeyed.(IJ)

צ Tsadhe

137 You are righteous,(IK) Lord,
    and your laws are right.(IL)
138 The statutes you have laid down are righteous;(IM)
    they are fully trustworthy.(IN)
139 My zeal wears me out,(IO)
    for my enemies ignore your words.
140 Your promises(IP) have been thoroughly tested,(IQ)
    and your servant loves them.(IR)
141 Though I am lowly and despised,(IS)
    I do not forget your precepts.(IT)
142 Your righteousness is everlasting
    and your law is true.(IU)
143 Trouble and distress have come upon me,
    but your commands give me delight.(IV)
144 Your statutes are always righteous;
    give me understanding(IW) that I may live.

ק Qoph

145 I call with all my heart;(IX) answer me, Lord,
    and I will obey your decrees.(IY)
146 I call out to you; save me(IZ)
    and I will keep your statutes.
147 I rise before dawn(JA) and cry for help;
    I have put my hope in your word.
148 My eyes stay open through the watches of the night,(JB)
    that I may meditate on your promises.
149 Hear my voice(JC) in accordance with your love;(JD)
    preserve my life,(JE) Lord, according to your laws.
150 Those who devise wicked schemes(JF) are near,
    but they are far from your law.
151 Yet you are near,(JG) Lord,
    and all your commands are true.(JH)
152 Long ago I learned from your statutes(JI)
    that you established them to last forever.(JJ)

ר Resh

153 Look on my suffering(JK) and deliver me,(JL)
    for I have not forgotten(JM) your law.
154 Defend my cause(JN) and redeem me;(JO)
    preserve my life(JP) according to your promise.(JQ)
155 Salvation is far from the wicked,
    for they do not seek out(JR) your decrees.
156 Your compassion, Lord, is great;(JS)
    preserve my life(JT) according to your laws.(JU)
157 Many are the foes who persecute me,(JV)
    but I have not turned(JW) from your statutes.
158 I look on the faithless with loathing,(JX)
    for they do not obey your word.(JY)
159 See how I love your precepts;
    preserve my life,(JZ) Lord, in accordance with your love.
160 All your words are true;
    all your righteous laws are eternal.(KA)

ש Sin and Shin

161 Rulers persecute me(KB) without cause,
    but my heart trembles(KC) at your word.
162 I rejoice(KD) in your promise
    like one who finds great spoil.(KE)
163 I hate and detest(KF) falsehood
    but I love your law.(KG)
164 Seven times a day I praise you
    for your righteous laws.(KH)
165 Great peace(KI) have those who love your law,
    and nothing can make them stumble.(KJ)
166 I wait for your salvation,(KK) Lord,
    and I follow your commands.
167 I obey your statutes,
    for I love them(KL) greatly.
168 I obey your precepts(KM) and your statutes,(KN)
    for all my ways are known(KO) to you.

ת Taw

169 May my cry come(KP) before you, Lord;
    give me understanding(KQ) according to your word.(KR)
170 May my supplication come(KS) before you;
    deliver me(KT) according to your promise.(KU)
171 May my lips overflow with praise,(KV)
    for you teach me(KW) your decrees.
172 May my tongue sing(KX) of your word,
    for all your commands are righteous.(KY)
173 May your hand be ready to help(KZ) me,
    for I have chosen(LA) your precepts.
174 I long for your salvation,(LB) Lord,
    and your law gives me delight.(LC)
175 Let me live(LD) that I may praise you,
    and may your laws sustain me.
176 I have strayed like a lost sheep.(LE)
    Seek your servant,
    for I have not forgotten(LF) your commands.

Footnotes

  1. Psalm 119:1 This psalm is an acrostic poem, the stanzas of which begin with successive letters of the Hebrew alphabet; moreover, the verses of each stanza begin with the same letter of the Hebrew alphabet.
  2. Psalm 119:33 Or follow it for its reward
  3. Psalm 119:37 Two manuscripts of the Masoretic Text and Dead Sea Scrolls; most manuscripts of the Masoretic Text life in your way
  4. Psalm 119:112 Or decrees / for their enduring reward