Add parallel Print Page Options

Àwọn ẹ̀yà ìkọjá odò Jordani

32 Àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi, tí wọ́n ní ẹran ọ̀sìn àti ohun ọ̀sìn rí wí pé ilẹ̀ Jaseri àti Gileadi dára fún ohun ọ̀sìn. Àwọn ọmọ Gadi àti àwọn ọmọ Reubeni sì wá, wọ́n wá sí ọ̀dọ̀ Mose àti Eleasari àlùfáà àti sí olórí gbogbo ìlú, wọ́n sì wí pé, “Atarotu, Diboni, Jaseri, Nimra, Heṣboni, Eleale, Sebamu, Nebo, àti Beoni. Ni ilẹ̀ tí Olúwa ti ṣẹ́gun níwájú ìjọ Israẹli tí ó sì dára fún ohun ọ̀sìn, ṣáwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì ní ohun ọ̀sìn. Tí a bá rí ojúrere rẹ,” wọ́n wí, “jẹ́ kí a fi ilẹ̀ yìí fún ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ìní. Má ṣe jẹ́ kí a rékọjá odò Jordani.”

Mose sọ fún àwọn ọmọ Gadi àti fún ọmọ Reubeni pé, “Ṣé kí àwọn arákùnrin yín lọ sí ogun, kí ẹ̀yin kí ó sì jókòó sí bí? Kí ni ó dé tí o fi mú ìrẹ̀wẹ̀sì bá àwọn ọmọ Israẹli láti lọ sí ibi ilẹ̀ tí Olúwa ti fi fún wọn? (A)Èyí ni nǹkan tí baba yín ṣe nígbà tí mo rán wọn láti Kadeṣi-Barnea láti lọ wo ilẹ̀ náà. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n lọ sí Àfonífojì Eṣkolu tí wọ́n rí ilẹ̀ náà, wọ́n mú ìrẹ̀wẹ̀sì bá àwọn ọmọ Israẹli láti wọ ilẹ̀ tí Olúwa ti fi fún wọn. 10 (B)Ìbínú Olúwa sì dìde sí wọn ní ọjọ́ náà, ó sì búra, wí pé: 11 ‘Nítorí wọn kò tẹ̀lé mi tọkàntọkàn, kì í ṣe ọ̀kan nínú àwọn ọkùnrin náà tí ó jẹ́ ogún ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ tí ó gòkè láti Ejibiti ni yóò rí ilẹ̀ tí mo pinnu gẹ́gẹ́ bí ìbúra fún Abrahamu, fún Isaaki àti fún Jakọbu: 12 kò sí ẹnìkankan àyàfi Kalebu ọmọ Jefunne ti Kenissiti àti Joṣua ọmọ Nuni, nítorí wọ́n tẹ̀lé Olúwa tọkàntọkàn.’ 13 Ìbínú Olúwa ru sí àwọn ọmọ Israẹli ó sì mú wọn rìn ní aginjù fún ogójì (40) ọdún, títí tí àwọn ìran tí wọ́n ṣe búburú ní ojú rẹ̀ fi lọ.

14 “Níbí ni ẹ̀yin wà, ẹ̀yin ẹlẹ́ṣẹ̀, ẹ̀yin dìde ní ipò baba yín, ẹ sì jẹ́ kí ìbínú gbígbóná Olúwa ru sí Israẹli. 15 Tí ẹ̀yin bá yípadà ní ẹ̀yìn rẹ̀ yóò sì fi àwọn ènìyàn wọ̀nyí sílẹ̀ ní aginjù, ìwọ yóò sì mú un ṣe ìparun.”

16 Nígbà náà wọ́n wá sí òkè ní ọ̀dọ̀ rẹ̀, “Àwa yóò fẹ́ láti kọ́ ilé ẹran níhìn-ín yìí fún ohun ọ̀sìn wa, àti ìlú fún àwọn obìnrin àti ọmọ wẹ́wẹ́ wa. 17 Ṣùgbọ́n àwa ṣetán láti dira ogun ṣáájú àwọn ọmọ Israẹli títí tí a yóò fi mú wọn dé ọ̀dọ̀ wọn lákokò yìí, àwọn obìnrin àti ọmọ wẹ́wẹ́ wa yóò gbé inú ìlú tí a mọ odi sí fún ìdáàbòbò wọn lọ́wọ́ olùgbé ilẹ̀ náà. 18 A kì yóò padà sí ilẹ̀ wa láìṣe pé gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ti gba ogún wọn. 19 A kì yóò gba ogún kankan pẹ̀lú wọn ní òdìkejì Jordani, nítorí ogún ti wa, ti wá sí ọ̀dọ̀ wa ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani.”

20 Nígbà náà ni Mose sọ fún wọn pé, “Tí ẹ̀yin yóò bá pa ara yín lára, níwájú Olúwa fún ogún. 21 Bí gbogbo yín yóò bá lọ sí Jordani ní ìhámọ́ra níwájú Olúwa, títí yóò fi lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ kúrò níwájú rẹ̀. 22 Tí a ó sì fi ṣe ilẹ̀ náà níwájú Olúwa; ẹ̀yin lè padà tí yóò sì di òmìnira lọ́wọ́ ìdè níwájú Olúwa àti Israẹli. Ilẹ̀ yìí yóò sì jẹ́ tiyín níwájú Olúwa.

23 “Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá kọ̀ láti ṣe èyí, ẹ̀yin yóò máa dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa; kí ẹ̀yin kí ó sì mọ̀ dájú pé ẹ̀ṣẹ̀ yín yóò fi yín hàn. 24 Ẹ kọ́ ilé fún àwọn obìnrin yín àti ọmọ wẹ́wẹ́ yín, àti ilé fún agbo ẹran yín, ṣùgbọ́n kí ẹ̀yin kí ó ṣe ohun tí ẹ ti pinnu.”

25 Àwọn ọmọ Gadi àti ọmọ Reubeni sọ fún Mose pé, “Àwa ìránṣẹ́ rẹ yóò ṣe gẹ́gẹ́ bí olúwa wa ti pàṣẹ. 26 Àwọn ọmọ wa àti ìyàwó wa, àwọn agbo ẹran àti ohun ọ̀sìn wa yóò dúró ní ìlú Gileadi. 27 Ṣùgbọ́n àwọn ìránṣẹ́ rẹ, gbogbo ọkùnrin tí ó wọ ìhámọ́ra ogun, yóò rékọjá lọ láti jà níwájú Olúwa; gẹ́gẹ́ bí olúwa wa ti sọ.”

28 Nígbà náà ni Mose pàṣẹ nípa wọn fún Eleasari àlùfáà àti Joṣua ọmọ Nuni àti sí gbogbo olórí ìdílé ẹ̀yà Israẹli. 29 Mose sì wí fún wọn pé, “Tí àwọn ọmọ Gadi àti ọmọ Reubeni, gbogbo ọkùnrin tí ó wọ ìhámọ́ra fún ogun rékọjá odò Jordani pẹ̀lú níwájú Olúwa, nígbà tí ẹ ṣẹ́gun ilẹ̀ náà níwájú yín, Fún wọn ní ilẹ̀ Gileadi gẹ́gẹ́ bí ìní wọn. 30 Ṣùgbọ́n tí wọn kò bá fẹ́ bá yín rékọjá pẹ̀lú ìhámọ́ra, wọn gbọdọ̀ gba ìní wọn pẹ̀lú yín ní Kenaani.”

31 Àwọn ọmọ Gadi àti ọmọ Reubeni dáhùn pé, “Ìránṣẹ́ rẹ yóò ṣe ohun tí Olúwa ti sọ. 32 A máa rékọjá níwájú Olúwa lọ sí Kenaani pẹ̀lú ìhámọ́ra, ṣùgbọ́n ẹrù tí a jogún yóò wà ní ẹ̀bá Jordani.”

33 Nígbà náà Mose fún àwọn ọmọ Gadi àti àwọn ọmọ Reubeni àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase ọmọ Josẹfu ní ilẹ̀ ọba Sihoni ọba àwọn ọmọ Amori àti ilẹ̀ ọba Ogu ọba Baṣani ní gbogbo ilẹ̀ náà pẹ̀lú ìlú rẹ̀ àti agbègbè tí ó yí i ka.

34 Àwọn ará Gadi wọ́n kọ́ Diboni, Atarotu, Aroeri; 35 Pẹ̀lú Atrotu Ṣofani, Jaseri, àti Jogbeha: 36 Pẹ̀lú Beti-Nimra, àti Beti-Harani ìlú olódi, àti agbo fún àgùntàn. 37 Àwọn ọmọ Reubeni sì kọ́ Heṣboni, Eleale, Kiriataimu, 38 pẹ̀lú Nebo pẹ̀lú Baali-Meoni, (Wọ́n pàrọ̀ orúkọ wọn) àti Sibma. Wọ́n sì sọ ìlú tí wọ́n tún kọ́ ní orúkọ mìíràn.

39 Àwọn ọmọ Makiri ọmọ Manase lọ sí Gileadi, wọ́n sì lé àwọn ọmọ Amori tí ó wà níbẹ̀. 40 Mose sì fi àwọn ọmọ Gileadi fún àwọn ọmọ Makiri àwọn ìran Manase, wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀. 41 Jairi, ọmọ Manase gba ibùjókòó wọn, ó sì pè wọ́n ní Haffotu Jairi. 42 Noba gba Kenati àti àwọn ìtẹ̀dó rẹ̀, ó sì pè é ní Noba lẹ́yìn orúkọ ara rẹ̀.

The Transjordan Tribes

32 The Reubenites and Gadites, who had very large herds and flocks,(A) saw that the lands of Jazer(B) and Gilead(C) were suitable for livestock.(D) So they came to Moses and Eleazar the priest and to the leaders of the community,(E) and said, “Ataroth,(F) Dibon,(G) Jazer,(H) Nimrah,(I) Heshbon,(J) Elealeh,(K) Sebam,(L) Nebo(M) and Beon(N) the land the Lord subdued(O) before the people of Israel—are suitable for livestock,(P) and your servants have livestock. If we have found favor in your eyes,” they said, “let this land be given to your servants as our possession. Do not make us cross the Jordan.(Q)

Moses said to the Gadites and Reubenites, “Should your fellow Israelites go to war while you sit here? Why do you discourage the Israelites from crossing over into the land the Lord has given them?(R) This is what your fathers did when I sent them from Kadesh Barnea to look over the land.(S) After they went up to the Valley of Eshkol(T) and viewed the land, they discouraged the Israelites from entering the land the Lord had given them. 10 The Lord’s anger was aroused(U) that day and he swore this oath:(V) 11 ‘Because they have not followed me wholeheartedly, not one of those who were twenty years old or more(W) when they came up out of Egypt(X) will see the land I promised on oath(Y) to Abraham, Isaac and Jacob(Z) 12 not one except Caleb son of Jephunneh the Kenizzite and Joshua son of Nun, for they followed the Lord wholeheartedly.’(AA) 13 The Lord’s anger burned against Israel(AB) and he made them wander in the wilderness forty years, until the whole generation of those who had done evil in his sight was gone.(AC)

14 “And here you are, a brood of sinners, standing in the place of your fathers and making the Lord even more angry with Israel.(AD) 15 If you turn away from following him, he will again leave all this people in the wilderness, and you will be the cause of their destruction.(AE)

16 Then they came up to him and said, “We would like to build pens(AF) here for our livestock(AG) and cities for our women and children. 17 But we will arm ourselves for battle[a] and go ahead of the Israelites(AH) until we have brought them to their place.(AI) Meanwhile our women and children will live in fortified cities, for protection from the inhabitants of the land. 18 We will not return to our homes until each of the Israelites has received their inheritance.(AJ) 19 We will not receive any inheritance with them on the other side of the Jordan, because our inheritance(AK) has come to us on the east side of the Jordan.”(AL)

20 Then Moses said to them, “If you will do this—if you will arm yourselves before the Lord for battle(AM) 21 and if all of you who are armed cross over the Jordan before the Lord until he has driven his enemies out before him(AN) 22 then when the land is subdued before the Lord, you may return(AO) and be free from your obligation to the Lord and to Israel. And this land will be your possession(AP) before the Lord.(AQ)

23 “But if you fail to do this, you will be sinning against the Lord; and you may be sure that your sin will find you out.(AR) 24 Build cities for your women and children, and pens for your flocks,(AS) but do what you have promised.(AT)

25 The Gadites and Reubenites said to Moses, “We your servants will do as our lord commands.(AU) 26 Our children and wives, our flocks and herds will remain here in the cities of Gilead.(AV) 27 But your servants, every man who is armed for battle, will cross over to fight(AW) before the Lord, just as our lord says.”

28 Then Moses gave orders about them(AX) to Eleazar the priest and Joshua son of Nun(AY) and to the family heads of the Israelite tribes.(AZ) 29 He said to them, “If the Gadites and Reubenites, every man armed for battle, cross over the Jordan with you before the Lord, then when the land is subdued before you,(BA) you must give them the land of Gilead as their possession.(BB) 30 But if they do not cross over(BC) with you armed, they must accept their possession with you in Canaan.(BD)

31 The Gadites and Reubenites answered, “Your servants will do what the Lord has said.(BE) 32 We will cross over before the Lord into Canaan armed,(BF) but the property we inherit will be on this side of the Jordan.(BG)

33 Then Moses gave to the Gadites,(BH) the Reubenites and the half-tribe of Manasseh(BI) son of Joseph the kingdom of Sihon king of the Amorites(BJ) and the kingdom of Og king of Bashan(BK)—the whole land with its cities and the territory around them.(BL)

34 The Gadites built up Dibon, Ataroth, Aroer,(BM) 35 Atroth Shophan, Jazer,(BN) Jogbehah,(BO) 36 Beth Nimrah(BP) and Beth Haran as fortified cities, and built pens for their flocks.(BQ) 37 And the Reubenites rebuilt Heshbon,(BR) Elealeh(BS) and Kiriathaim,(BT) 38 as well as Nebo(BU) and Baal Meon (these names were changed) and Sibmah.(BV) They gave names to the cities they rebuilt.

39 The descendants of Makir(BW) son of Manasseh went to Gilead,(BX) captured it and drove out the Amorites(BY) who were there. 40 So Moses gave Gilead to the Makirites,(BZ) the descendants of Manasseh, and they settled there. 41 Jair,(CA) a descendant of Manasseh, captured their settlements and called them Havvoth Jair.[b](CB) 42 And Nobah captured Kenath(CC) and its surrounding settlements and called it Nobah(CD) after himself.(CE)

Footnotes

  1. Numbers 32:17 Septuagint; Hebrew will be quick to arm ourselves
  2. Numbers 32:41 Or them the settlements of Jair