Add parallel Print Page Options

Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ nípa Ninefe. Ìwé ìran Nahumu ará Elkoṣi.

Ìbínú Olúwa sí Ninefe

Ọlọ́run ń jẹ owú, ó sì ń gbẹ̀san.
    Olúwa ń gbẹ̀san, ó sì kún fún ìbínú
Olúwa ń gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá rẹ̀,
    Ìbínú rẹ̀ kò sì yí padà lórí àwọn ọ̀tá rẹ̀
(A)Olúwa lọ́ra láti bínú, ó sì tóbi ní agbára;
    Olúwa kì yóò fi àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ sílẹ̀ láìjìyà.
Ọ̀nà rẹ̀ wà nínú afẹ́fẹ́ àti nínú ìjì,
    Ìkùùkuu sánmọ̀ sì ni eruku ẹsẹ̀ rẹ̀.
Ó bá Òkun wí, ó sì mú kí ó gbẹ;
    Ó sìsọ gbogbo odò di gbígbẹ.
Baṣani àti Karmeli sì rọ,
    Ìtànná Lebanoni sì rẹ̀ sílẹ̀.
Àwọn òkè ńlá wárìrì níwájú rẹ̀,
    àwọn òkè kéékèèkéé sì di yíyọ́,
ilẹ̀ ayé sì jóná níwájú rẹ̀,
    àní ayé àti gbogbo àwọn tí ń gbé inú rẹ̀.
Ta ni ó lé dúró níwájú ìbínú rẹ̀?
    Ta ni ó lé faradà gbígbóná ìbínú rẹ̀?
Ìbínú rẹ̀ tú jáde bí iná;
    àwọn àpáta sì fọ́ túútúú níwájú rẹ̀.

Rere ni Olúwa,
    òun ni ààbò ní ọjọ́ ìpọ́njú.
Òun sì tọ́jú àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé e,
    Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìkún omi ńlá
ní òun yóò fi ṣe ìparun láti ibẹ̀ dé òpin;
    òkùnkùn yóò sì máa lépa àwọn ọ̀tá rẹ̀.

Kí ni ẹ̀yìn ń gbìmọ̀ lòdì sí Olúwa?
    Òun yóò fi òpin sí i,
    ìpọ́njú kì yóò wáyé ní ìgbà kejì
10 Wọn yóò sì lọ́lù papọ̀ bí ẹ̀gún òṣùṣú
    wọn yóò sì mu àmupara nínú ọtí wáìnì wọn
    a ó sì run wọn gẹ́gẹ́ bi àgékù koríko gbígbẹ
11 Láti ọ̀dọ̀ rẹ, ìwọ Ninefe, ni ẹnìkan ti jáde wá
    tí ó ń gbèrò ibi sí Olúwa
    ti ó sì ń gbìmọ̀ búburú.

12 Báyìí ni Olúwa wí:

“Bí wọ́n tilẹ̀ ni ìfọwọ́sowọ́pọ̀, tí wọ́n sì pọ̀ níye,
    Ṣùgbọ́n, báyìí ní a ó ké wọn lulẹ̀,
nígbà tí òun ó bá kọjá.
    Bí mo tilẹ̀ ti pọ́n ọ lójú ìwọ Juda, èmi kì yóò pọ́n ọ lójú mọ́.
13 Nísinsin yìí ni èmi yóò já àjàgà wọn kúrò ní ọrùn rẹ
    èmi yóò já ṣẹkẹ́ṣẹkẹ̀ rẹ dànù.”

14 Olúwa ti fi àṣẹ kan lélẹ̀ nítorí tìrẹ Ninefe:
    “Ìwọ kì yóò ni irú-ọmọ láti máa jẹ́ orúkọ rẹ mọ́,
Èmi yóò pa ère fínfín àti ère dídà run
    tí ó wà nínú tẹmpili àwọn ọlọ́run rẹ.
Èmi yóò wa ibojì rẹ,
    nítorí ẹ̀gbin ni ìwọ.”

15 (B)Wò ó, lórí àwọn òkè,
    àwọn ẹsẹ̀ ẹni tí ó mú ìròyìn ayọ̀ wá,
    ẹni tí ó ń kéde àlàáfíà,
Ìwọ Juda, pa àṣẹ rẹ tí ó ní ìrònú mọ́,
    kí ó sì san àwọn ẹ̀jẹ́ rẹ.
Àwọn ènìyàn búburú kì yóò sì gbóguntì ọ́ mọ́;
    wọn yóò sì parun pátápátá.

A prophecy(A) concerning Nineveh.(B) The book of the vision(C) of Nahum the Elkoshite.

The Lord’s Anger Against Nineveh

The Lord is a jealous(D) and avenging God;
    the Lord takes vengeance(E) and is filled with wrath.
The Lord takes vengeance on his foes
    and vents his wrath against his enemies.(F)
The Lord is slow to anger(G) but great in power;
    the Lord will not leave the guilty unpunished.(H)
His way is in the whirlwind(I) and the storm,(J)
    and clouds(K) are the dust of his feet.
He rebukes(L) the sea and dries it up;(M)
    he makes all the rivers run dry.
Bashan and Carmel(N) wither
    and the blossoms of Lebanon fade.
The mountains quake(O) before him
    and the hills melt away.(P)
The earth trembles(Q) at his presence,
    the world and all who live in it.(R)
Who can withstand(S) his indignation?
    Who can endure(T) his fierce anger?(U)
His wrath is poured out like fire;(V)
    the rocks are shattered(W) before him.

The Lord is good,(X)
    a refuge in times of trouble.(Y)
He cares for(Z) those who trust in him,(AA)
    but with an overwhelming flood(AB)
he will make an end of Nineveh;
    he will pursue his foes into the realm of darkness.

Whatever they plot(AC) against the Lord
    he will bring[a] to an end;
    trouble will not come a second time.
10 They will be entangled among thorns(AD)
    and drunk(AE) from their wine;
    they will be consumed like dry stubble.[b](AF)
11 From you, Nineveh, has one come forth
    who plots evil against the Lord
    and devises wicked plans.

12 This is what the Lord says:

“Although they have allies and are numerous,
    they will be destroyed(AG) and pass away.
Although I have afflicted you, Judah,
    I will afflict you no more.(AH)
13 Now I will break their yoke(AI) from your neck
    and tear your shackles away.”(AJ)

14 The Lord has given a command concerning you, Nineveh:
    “You will have no descendants to bear your name.(AK)
I will destroy the images(AL) and idols
    that are in the temple of your gods.
I will prepare your grave,(AM)
    for you are vile.”

15 Look, there on the mountains,
    the feet of one who brings good news,(AN)
    who proclaims peace!(AO)
Celebrate your festivals,(AP) Judah,
    and fulfill your vows.
No more will the wicked invade you;(AQ)
    they will be completely destroyed.[c]

Footnotes

  1. Nahum 1:9 Or What do you foes plot against the Lord? / He will bring it
  2. Nahum 1:10 The meaning of the Hebrew for this verse is uncertain.
  3. Nahum 1:15 In Hebrew texts this verse (1:15) is numbered 2:1.