Add parallel Print Page Options

Israẹli olórí kunkun

48 “Tẹ́tí sí èyí, ìwọ ilé e Jakọbu,
    ìwọ tí a ń pè pẹ̀lú orúkọ Israẹli
tí o sì wá láti ẹ̀ka Juda,
    ìwọ tí ò ń búra ní orúkọ Olúwa
tí o sì ń pe Ọlọ́run Israẹli
    ṣùgbọ́n kì í ṣe ní òtítọ́ àti òdodo
Ìwọ tí ò ń pe ara rẹ ní ọmọ ìlú mímọ́ n nì
    tí o sì gbẹ́kẹ̀lé Ọlọ́run Israẹli—
    Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀:
Èmi sọ àsọtẹ́lẹ̀ àwọn nǹkan ti tẹ́lẹ̀ lọ́jọ́ tó ti pẹ́,
    ẹnu mi ló ti kéde wọn, mo sì sọ wọ́n di mí mọ̀;
    Lẹ́yìn náà lójijì mo gbé ìgbésẹ̀, wọ́n sì wá sí ìmúṣẹ.
Nítorí mo mọ bí ẹ ti jẹ́ olórí kunkun tó;
    àwọn iṣan ọrùn un yín irin ni wọ́n;
    iwájú yín idẹ ni
Nítorí náà mo ti sọ nǹkan wọ̀nyí fún ọ
    ní ọjọ́ tí ó ti pẹ́;
kí wọn ó tó ṣẹlẹ̀ mo ti kéde wọn fún un yín
    tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ kò fi lè sọ pé,
‘Àwọn ère mi ló ṣe wọ́n;
    àwọn ère igi àti òrìṣà irin ló fọwọ́sí i.’
Ìwọ ti gbọ́ àwọn nǹkan wọ̀nyí; wo gbogbo wọn
    Ǹjẹ́ o kò nígbà wọ́n bí?

“Láti ìsinsin yìí lọ, Èmi yóò máa sọ
    fún ọ nípa nǹkan tuntun,
    àwọn nǹkan tí ó fi ara sin tí ìwọ kò mọ̀.
A dá wọn ní àkókò yìí kì í ṣe láti ìgbà pípẹ́
    ìwọ kò tí ì gbọ́ nípa wọn títí di òní.
Nítorí náà, ìwọ kò lè sọ pé,
    ‘Bẹ́ẹ̀ ni, mo mọ̀ nípa wọn.’
Ìwọ a ha ti gbọ́ tàbí ó ti yé ọ bí
láti ìgbà àtijọ́ etí kò ti di yíyà.
    Ǹjẹ́ mo mọ̀ bí o ti jẹ́ alárékérekè tó;
    a ń pè ọ́ ní ọlọ̀tẹ̀ láti ìgbà ìbí rẹ.
Nítorí orúkọ ara mi, mo dáwọ́ ìbínú mi dúró;
    nítorí ìyìn ara mi, mo fà á sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ rẹ,
    kí a má ba à ké ọ kúrò.
10 Wò ó, èmi ti tún ọ ṣe, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé
    kì í ṣe bí i fàdákà;
    Èmi ti dán ọ wò nínú ìléru ìpọ́njú.
11 Nítorí orúkọ mi, nítorí orúkọ mi, mo ṣe èyí
    Báwo ni mo ṣe lè jẹ́ kí a ba orúkọ mi jẹ́.
    Èmi kì yóò fi ògo mi fún ẹlòmíràn.

Israẹli dòmìnira

12 (A)“Tẹ́tí sí mi, ìwọ Jakọbu
    Israẹli ẹni tí mo pè:
Èmi ni ẹni náà;
    Èmi ni ẹni àkọ́kọ́ àti ẹni ìgbẹ̀yìn.
13 Ọwọ́ mi pàápàá ni ó fi àwọn ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀,
    àti ọwọ́ ọ̀tún mi ni ó tẹ àwọn ọ̀run;
nígbà tí mo pè wọ́n,
    gbogbo wọn dìde sókè papọ̀.

14 “Gbogbo yín, ẹ péjọ kí ẹ sì gbọ́:
    Ta nínú wọn ni ó ti sọ nǹkan wọ̀nyí.
Olúwa ti fẹ́ ẹ,
    yóò sì ṣe ìfẹ́ rẹ̀ ní Babiloni,
    apá rẹ̀ ni yóò sì wà ní ará àwọn ará Kaldea.
15 Èmi, àní Èmi ló ti sọ̀rọ̀;
    bẹ́ẹ̀ ni, mo ti pè é.
Èmi yóò mú un wá,
    òun yóò sì ṣe àṣeyọrí nínú ìrìnàjò rẹ̀.

16 “Ẹ súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi kí ẹ sì dẹtí sí èyí:

“Láti ìgbà ìkéde àkọ́kọ́ èmi kò sọ̀rọ̀ ní ìkọ̀kọ̀;
    ní àsìkò tí ó sì ṣẹlẹ̀, Èmi wà níbẹ̀.”

Àti ní àkókò yìí, Olúwa Olódùmarè ni ó ti rán mi,
    pẹ̀lú ẹ̀mí rẹ̀.

17 Èyí ni ohun tí Olúwa
    Olùdáǹdè rẹ, Ẹni Mímọ́ Israẹli:
“Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ,
    tí ó kọ́ ọ ní ohun tí ó dára fún ọ,
    tí ó tọ́ ọ ṣọ́nà tí ó yẹ kí o máa rìn.
18 Bí ó bá ṣe pé ìwọ bá ti tẹ́tí sílẹ̀ sí àṣẹ mi,
    àlàáfíà rẹ kì bá ti dàbí ì ti odò,
    àti òdodo rẹ bí ìgbì Òkun.
19 Àwọn ọmọ rẹ ìbá ti dàbí iyanrìn,
    àwọn ọmọ yín bí i hóró ọkà tí a kò lè kà tán;
orúkọ wọn ni a kì yóò ké kúrò
    tàbí kí a pa wọ́n run níwájú mi.”

20 Fi Babeli sílẹ̀,
    sá fún àwọn ará Babeli,
ṣe ìfilọ̀ èyí pẹ̀lú ariwo ayọ̀
    kí o sì kéde rẹ̀.
Rán an jáde lọ sí òpin ilẹ̀ ayé;
    wí pé, “Olúwa ti dá ìránṣẹ́ rẹ̀ Jakọbu nídè.”
21 Òrùngbẹ kò gbẹ wọ́n nígbà tí ó kó wọn
    kọjá nínú aginjù;
ó jẹ́ kí omi ó sàn fún wọn láti inú àpáta;
    ó fọ́ àpáta
    omi sì tú jáde.

22 “Kò sí àlàáfíà,” ni Olúwa wí,
    “Fún àwọn ìkà.”

Stubborn Israel

48 “Listen to this, you descendants of Jacob,
    you who are called by the name of Israel(A)
    and come from the line of Judah,(B)
you who take oaths(C) in the name of the Lord(D)
    and invoke(E) the God of Israel—
    but not in truth(F) or righteousness—
you who call yourselves citizens of the holy city(G)
    and claim to rely(H) on the God of Israel—
    the Lord Almighty is his name:(I)
I foretold the former things(J) long ago,
    my mouth announced(K) them and I made them known;
    then suddenly(L) I acted, and they came to pass.
For I knew how stubborn(M) you were;
    your neck muscles(N) were iron,
    your forehead(O) was bronze.
Therefore I told you these things long ago;
    before they happened I announced(P) them to you
so that you could not say,
    ‘My images brought them about;(Q)
    my wooden image and metal god ordained them.’
You have heard these things; look at them all.
    Will you not admit them?

“From now on I will tell you of new things,(R)
    of hidden things unknown to you.
They are created(S) now, and not long ago;(T)
    you have not heard of them before today.
So you cannot say,
    ‘Yes, I knew(U) of them.’
You have neither heard nor understood;(V)
    from of old your ears(W) have not been open.
Well do I know how treacherous(X) you are;
    you were called a rebel(Y) from birth.
For my own name’s sake(Z) I delay my wrath;(AA)
    for the sake of my praise I hold it back from you,
    so as not to destroy you completely.(AB)
10 See, I have refined(AC) you, though not as silver;
    I have tested(AD) you in the furnace(AE) of affliction.
11 For my own sake,(AF) for my own sake, I do this.
    How can I let myself be defamed?(AG)
    I will not yield my glory to another.(AH)

Israel Freed

12 “Listen(AI) to me, Jacob,
    Israel, whom I have called:(AJ)
I am he;(AK)
    I am the first and I am the last.(AL)
13 My own hand laid the foundations of the earth,(AM)
    and my right hand spread out the heavens;(AN)
when I summon them,
    they all stand up together.(AO)

14 “Come together,(AP) all of you, and listen:
    Which of the idols has foretold(AQ) these things?
The Lord’s chosen ally(AR)
    will carry out his purpose(AS) against Babylon;(AT)
    his arm will be against the Babylonians.[a]
15 I, even I, have spoken;
    yes, I have called(AU) him.
I will bring him,
    and he will succeed(AV) in his mission.

16 “Come near(AW) me and listen(AX) to this:

“From the first announcement I have not spoken in secret;(AY)
    at the time it happens, I am there.”

And now the Sovereign Lord(AZ) has sent(BA) me,
    endowed with his Spirit.(BB)

17 This is what the Lord says—
    your Redeemer,(BC) the Holy One(BD) of Israel:
“I am the Lord your God,
    who teaches(BE) you what is best for you,
    who directs(BF) you in the way(BG) you should go.
18 If only you had paid attention(BH) to my commands,
    your peace(BI) would have been like a river,(BJ)
    your well-being(BK) like the waves of the sea.
19 Your descendants(BL) would have been like the sand,(BM)
    your children like its numberless grains;(BN)
their name would never be blotted out(BO)
    nor destroyed from before me.”

20 Leave Babylon,
    flee(BP) from the Babylonians!
Announce this with shouts of joy(BQ)
    and proclaim it.
Send it out to the ends of the earth;(BR)
    say, “The Lord has redeemed(BS) his servant Jacob.”
21 They did not thirst(BT) when he led them through the deserts;
    he made water flow(BU) for them from the rock;
he split the rock
    and water gushed out.(BV)

22 “There is no peace,”(BW) says the Lord, “for the wicked.”(BX)

Footnotes

  1. Isaiah 48:14 Or Chaldeans; also in verse 20