Add parallel Print Page Options

Májẹ̀mú Ọlọ́run pẹ̀lú Abramu

15 Lẹ́yìn èyí, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Abramu wá lójú ìran pé:

“Abramu má ṣe bẹ̀rù,
    Èmi ni ààbò rẹ,
    Èmi sì ni èrè ńlá rẹ.”

Ṣùgbọ́n Abramu wí pé, “Olúwa Olódùmarè, kí ni ìwọ yóò fi fún mi níwọ̀n ìgbà tí èmi kò bímọ, Elieseri ará Damasku ni yóò sì jogún mi,” Abramu sì tún tẹ̀síwájú pé, “Ìwọ kò fún mi ní ọmọ, nítorí náà ẹrú nínú ilé mi sì ni yóò jẹ́ àrólé mi.”

(A)Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tún tọ̀ ọ́ wá pé: “Ọkùnrin yìí kọ́ ni yóò jẹ́ àrólé rẹ bí kò ṣe ọmọ tí ìwọ bí fúnrarẹ̀ ni yóò jẹ́ àrólé rẹ.” (B)Olúwa sì mú Abramu jáde sí ìta ó sì wí fún un pé, “Gbé ojú sókè sí ọ̀run kí o sì ka àwọn ìràwọ̀ bí ó bá ṣe pé ìwọ le è kà wọ́n.” Ó sì wí fun un pé, “Nítorí náà, báyìí ni irú-ọmọ rẹ yóò rí.”

(C)Abramu gba Ọlọ́run gbọ́, a sì kà á sí òdodo fún un.

Ó sì tún wí fún un pé, “Èmi ni Olúwa tí ó mú ọ jáde láti Uri ti Kaldea láti fún ọ ní ilẹ̀ yìí láti jogún.”

Ṣùgbọ́n Abramu wí pé, “Olúwa Olódùmarè, báwo ni mo ṣe lè mọ̀ pé ilẹ̀ náà yóò jẹ́ ohun ìní mi?”

Nítorí náà, Olúwa wí fún un pé, “Mú abo màlúù, ewúrẹ́ àti àgbò ọlọ́dún mẹ́ta mẹ́ta wá, àti àdàbà kan àti ọmọ ẹyẹlé kan.”

10 Abramu sì mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí wá, ó sì là wọ́n sí méjì méjì, ó sì fi ẹ̀là èkínní kọjú sí èkejì, ṣùgbọ́n kò la àwọn ẹyẹ ní tiwọn. 11 Àwọn ẹyẹ igún sì ń wá sórí òkú ẹran náà, Abramu sì ń lé wọn.

12 (D)Bí oòrùn ti ń wọ̀, Abramu sùn lọ fọnfọn, òkùnkùn biribiri tí ó kún fún ẹ̀rù sì bò ó. 13 (E)(F)Nígbà náà ni Olúwa wí fún Abramu pé, “Mọ èyí dájú pé, irú-ọmọ rẹ yóò ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì, wọn ó sì sọ wọn di ẹrú, wọn ó sì pọ́n wọn lójú fún irínwó ọdún (400). 14 Ṣùgbọ́n orílẹ̀-èdè náà tí wọn yóò máa sìn, ni èmi ó dá lẹ́jọ́, lẹ́yìn náà ni wọn ó sì jáde pẹ̀lú ọrọ̀ púpọ̀. 15 Ṣùgbọ́n ìwọ yóò tọ àwọn baba rẹ lọ ni àlàáfíà, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ yóò sì di arúgbó kí a tó gbé ọ sin. 16 Ní ìran kẹrin àwọn ìran rẹ yóò padà wá sí ibi. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ará Amori kò ì tí ì kún òṣùwọ̀n.”

17 Nígbà tí oòrùn wọ̀ tí ilẹ̀ sì ṣú, ìkòkò iná tí ń ṣèéfín àti ọwọ́ iná sì ń kọjá láàrín ẹ̀là ẹran náà. 18 (G)Ní ọjọ́ náà gan an ni Olúwa dá májẹ̀mú pẹ̀lú Abramu, ó sì wí pé, “Àwọn ìran rẹ ni èmi yóò fi ilẹ̀ yìí fún, láti odò Ejibiti dé odò ńlá Eufurate: 19 ilẹ̀ àwọn ará Keni, àti ti ará Kenissiti, àti ará Kadmoni, 20 àti ti ará Hiti, àti ti ará Peresi, àti ti ará Refaimu. 21 Àti ti ará Amori, àti ti ará Kenaani, àti ti ará Girgaṣi àti ti ará Jebusi.”

The Lord’s Covenant With Abram

15 After this, the word of the Lord came to Abram(A) in a vision:(B)

“Do not be afraid,(C) Abram.
    I am your shield,[a](D)
    your very great reward.[b](E)

But Abram said, “Sovereign Lord,(F) what can you give me since I remain childless(G) and the one who will inherit[c] my estate is Eliezer of Damascus?(H) And Abram said, “You have given me no children; so a servant(I) in my household(J) will be my heir.”

Then the word of the Lord came to him: “This man will not be your heir, but a son who is your own flesh and blood will be your heir.(K) He took him outside and said, “Look up at the sky and count the stars(L)—if indeed you can count them.” Then he said to him, “So shall your offspring[d] be.”(M)

Abram believed the Lord, and he credited it to him as righteousness.(N)

He also said to him, “I am the Lord, who brought you out(O) of Ur of the Chaldeans(P) to give you this land to take possession of it.”(Q)

But Abram said, “Sovereign Lord,(R) how can I know(S) that I will gain possession of it?”(T)

So the Lord said to him, “Bring me a heifer,(U) a goat and a ram, each three years old,(V) along with a dove and a young pigeon.(W)

10 Abram brought all these to him, cut them in two and arranged the halves opposite each other;(X) the birds, however, he did not cut in half.(Y) 11 Then birds of prey came down on the carcasses,(Z) but Abram drove them away.

12 As the sun was setting, Abram fell into a deep sleep,(AA) and a thick and dreadful darkness came over him. 13 Then the Lord said to him, “Know for certain that for four hundred years(AB) your descendants will be strangers in a country not their own and that they will be enslaved(AC) and mistreated there. 14 But I will punish the nation they serve as slaves, and afterward they will come out(AD) with great possessions.(AE) 15 You, however, will go to your ancestors(AF) in peace and be buried at a good old age.(AG) 16 In the fourth generation(AH) your descendants will come back here,(AI) for the sin of the Amorites(AJ) has not yet reached its full measure.”

17 When the sun had set and darkness had fallen, a smoking firepot with a blazing torch(AK) appeared and passed between the pieces.(AL) 18 On that day the Lord made a covenant with Abram(AM) and said, “To your descendants I give this land,(AN) from the Wadi[e] of Egypt(AO) to the great river, the Euphrates(AP) 19 the land of the Kenites,(AQ) Kenizzites, Kadmonites, 20 Hittites,(AR) Perizzites,(AS) Rephaites,(AT) 21 Amorites, Canaanites, Girgashites and Jebusites.”(AU)

Footnotes

  1. Genesis 15:1 Or sovereign
  2. Genesis 15:1 Or shield; / your reward will be very great
  3. Genesis 15:2 The meaning of the Hebrew for this phrase is uncertain.
  4. Genesis 15:5 Or seed
  5. Genesis 15:18 Or river