Add parallel Print Page Options

Daniẹli rí ìran ọkùnrin kan

10 Ní ọdún kẹta Kirusi ọba Persia, a fi ìran kan hàn Daniẹli (ẹni tí à ń pè ní Belteṣassari). Òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ ìran náà, ó sì ní í ṣe pẹ̀lú àsìkò ìpọ́njú ńlá, òye ọ̀rọ̀ náà wá bá a nínú ìran.

Ní àsìkò náà, èmi Daniẹli ṣọ̀fọ̀ fún ọ̀sẹ̀ mẹ́ta. Èmi kì í jẹ oúnjẹ tí ó dára, èmi kò fi ẹran tàbí wáìnì kan ẹnu mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò fi òróró para títí ọ̀sẹ̀ mẹ́ta fi kọjá.

Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù àkọ́kọ́, bí mo ti dúró sí etí i bèbè odò ńlá Tigirisi, (A)Mo wo òkè, mo rí ọkùnrin kan tí ó wọ aṣọ àlà, ẹ̀gbẹ́ ẹni tí a fi wúrà Upasi dáradára dì ní àmùrè. Ara rẹ̀ dàbí berili, ojú u rẹ̀ dàbí mọ̀nàmọ́ná, ẹyin ojú u rẹ̀ dàbí iná àtẹ̀tàn, apá àti ẹsẹ̀ rẹ̀ dàbí ìtànná ìmọ́lẹ̀ tí o kún fún idẹ, àti ohùn rẹ̀ dàbí i ti ìjọ ènìyàn púpọ̀.

Èmi Daniẹli, ni ẹnìkan tí ó rí ìran náà, àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú u mi, wọn kò rí i, ṣùgbọ́n ìpayà ńlá dà bò wọ́n, wọ́n sálọ wọ́n sì fi ara pamọ́. Ó sì ku èmi nìkan, tí mo rí ìran ńlá yìí, kò sì ku okun kankan fún mi, ojú u mi sì rẹ̀wẹ̀sì gidigidi, n kò sì ní agbára mọ́. Nígbà náà, ni mo gbọ́ tí ó ń sọ̀rọ̀, bí mo ṣe tẹ́tí sílẹ̀ sí i, mo sùn lọ fọnfọn, ní ìdojúbolẹ̀.

10 Ọwọ́ kan kàn mí, ó gbé mi dìde ní ìwárìrì lórí ọwọ́ àti eékún mi. 11 Ó sọ pé, “Daniẹli ẹni tí a yàn fẹ́ gidigidi gba ọ̀rọ̀ tí mo fẹ́ bá ọ sọ yìí yẹ̀ wò dáradára, kí o sì dìde, nítorí tí a rán mi sí ọ.” Bí ó ṣe sọ èyí fún mi, mo dìde ní ìwárìrì.

12 Nígbà náà ni ó tẹ̀síwájú, pé, “Má ṣe bẹ̀rù Daniẹli. Láti ọjọ́ àkọ́kọ́ tí ìwọ ti fi ọkàn rẹ sílẹ̀ níwájú Ọlọ́run rẹ, a gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ, mo sì wá nítorí ọ̀rọ̀ náà. 13 (B)Ṣùgbọ́n ọmọ-aládé ìjọba Persia dá mi dúró fún ọjọ́mọ́kànlélógún. Nígbà náà ni Mikaeli, ọ̀kan lára ìjòyè àwọn ọmọ-aládé, wá láti ràn mi lọ́wọ́, nítorí a dá mi dúró níbẹ̀ pẹ̀lú ọba Persia. 14 Ní ìsinsin yìí mo wá láti ṣàlàyé ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí àwọn ènìyàn rẹ ní ọjọ́ iwájú, nítorí ìran náà ń sọ nípa ọjọ́ iwájú.”

15 Bí ó sì ti ń sọ nǹkan wọ̀nyí fún mi, mo sì dorí kodò mo sì dákẹ́. 16 Nígbà náà, ni ẹnìkan tí ó rí bí ènìyàn fi ọwọ́ kan ètè mi, mo la ẹnu mi, mo sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ ọ̀rọ̀, mo sọ fún ẹni tí ó dúró níwájú mi, “Ìrònú sì mú mi, nítorí ìran náà, olúwa mi, n kò sì ní okun. 17 Ǹjẹ́ báwo ni èmi ìránṣẹ́ ẹ̀ rẹ ṣe lè bá ọ sọ̀rọ̀, olúwa mi? Agbára mi ti lọ, agbára káká ni mo fi ń mí.”

18 Ẹ̀wẹ̀, ẹnìkan tí ó rí bí ènìyàn fi ọwọ́ kàn mí, ó sì fún mi ní agbára. 19 Ó sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ ọkùnrin olùfẹ́ gidigidi. Àlàáfíà ni fún ọ, mú ara le, àní mú ara le.”

Nígbà tí ohun bá mi sọ̀rọ̀, a sì mú mi lára le. “Mo sì wí pé, kí olúwa mi kí ó máa sọ̀rọ̀, níwọ̀n ìgbà tí ìwọ ti mú mi ní ara le.”

20 Nígbà náà, ni ó wí pé, “Ṣé o mọ ìdí tí mo fi tọ̀ ọ́ wá? Láìpẹ́ èmi yóò yípadà lọ bá àwọn ọmọ-aládé Persia jà, nígbà tí mo bá lọ àwọn ọmọ-aládé Giriki yóò wá; 21 ṣùgbọ́n ní àkọ́kọ́, èmi yóò sọ ohun tí wọ́n kọ sínú ìwé òtítọ́ fún ọ. (Kò sí ẹni tí ó kún mi lọ́wọ́ fún nǹkan wọ̀nyí bí kò ṣe Mikaeli, ọmọ-aládé e yín.

Daniel’s Vision of a Man

10 In the third year of Cyrus(A) king of Persia, a revelation was given to Daniel (who was called Belteshazzar).(B) Its message was true(C) and it concerned a great war.[a] The understanding of the message came to him in a vision.

At that time I, Daniel, mourned(D) for three weeks. I ate no choice food; no meat or wine touched my lips;(E) and I used no lotions at all until the three weeks were over.

On the twenty-fourth day of the first month, as I was standing on the bank(F) of the great river, the Tigris,(G) I looked up(H) and there before me was a man dressed in linen,(I) with a belt of fine gold(J) from Uphaz around his waist. His body was like topaz,(K) his face like lightning,(L) his eyes like flaming torches,(M) his arms and legs like the gleam of burnished bronze,(N) and his voice(O) like the sound of a multitude.

I, Daniel, was the only one who saw the vision; those who were with me did not see it,(P) but such terror overwhelmed them that they fled and hid themselves. So I was left alone,(Q) gazing at this great vision; I had no strength left,(R) my face turned deathly pale(S) and I was helpless.(T) Then I heard him speaking, and as I listened to him, I fell into a deep sleep, my face to the ground.(U)

10 A hand touched me(V) and set me trembling on my hands and knees.(W) 11 He said, “Daniel, you who are highly esteemed,(X) consider carefully the words I am about to speak to you, and stand up,(Y) for I have now been sent to you.” And when he said this to me, I stood up trembling.

12 Then he continued, “Do not be afraid,(Z) Daniel. Since the first day that you set your mind to gain understanding and to humble(AA) yourself before your God, your words(AB) were heard, and I have come in response to them.(AC) 13 But the prince(AD) of the Persian kingdom resisted me twenty-one days. Then Michael,(AE) one of the chief princes, came to help me, because I was detained there with the king of Persia. 14 Now I have come to explain(AF) to you what will happen to your people in the future,(AG) for the vision concerns a time yet to come.(AH)

15 While he was saying this to me, I bowed with my face toward the ground and was speechless.(AI) 16 Then one who looked like a man[b] touched my lips, and I opened my mouth and began to speak.(AJ) I said to the one standing before me, “I am overcome with anguish(AK) because of the vision, my lord, and I feel very weak. 17 How can I, your servant, talk with you, my lord? My strength is gone and I can hardly breathe.”(AL)

18 Again the one who looked like a man touched(AM) me and gave me strength.(AN) 19 “Do not be afraid, you who are highly esteemed,”(AO) he said. “Peace!(AP) Be strong now; be strong.”(AQ)

When he spoke to me, I was strengthened and said, “Speak, my lord, since you have given me strength.”(AR)

20 So he said, “Do you know why I have come to you? Soon I will return to fight against the prince of Persia, and when I go, the prince of Greece(AS) will come; 21 but first I will tell you what is written in the Book of Truth.(AT) (No one supports me against them except Michael,(AU) your prince.

Footnotes

  1. Daniel 10:1 Or true and burdensome
  2. Daniel 10:16 Most manuscripts of the Masoretic Text; one manuscript of the Masoretic Text, Dead Sea Scrolls and Septuagint Then something that looked like a human hand