Add parallel Print Page Options

Rubeni

(A)Ǹjẹ́ àwọn ọmọ Reubeni, àkọ́bí Israẹli. (Nítorí òun ni àkọ́bí; ṣùgbọ́n, bí ó ti ṣe pé ó ba ibùsùn baba rẹ̀ jẹ́, a fi ogún ìbí rẹ̀ fún àwọn ọmọ Josẹfu ọmọ Israẹli: a kì yóò sì ka ìtàn ìdílé náà gẹ́gẹ́ bí ipò ìbí. Nítorí Juda borí àwọn arákùnrin rẹ̀, àti lọ́dọ̀ rẹ̀ ni aláṣẹ ti ń jáde wá; ṣùgbọ́n ogún ìbí jẹ́ ti Josẹfu), àwọn ọmọ Reubeni àkọ́bí Israẹli ni:

Hanoku àti Pallu, Hesroni àti Karmi.

Àwọn ọmọ Joeli:

Ṣemaiah ọmọ rẹ̀, Gogu ọmọ rẹ̀,

Ṣimei ọmọ rẹ̀. Mika ọmọ rẹ̀,

Reaiah ọmọ rẹ̀, Baali ọmọ rẹ̀.

Beera ọmọ rẹ̀, tí Tiglat-Pileseri ọba Asiria kó ní ìgbèkùn lọ. Ìjòyè àwọn ọmọ Reubeni ni Beera jẹ́.

Àti àwọn arákùnrin rẹ̀ nípa ìdílé wọn, nígbà tí a ń ka ìtàn ìdílé ìran wọn:

Jeieli àti Sekariah ni olórí, àti Bela ọmọ Asasi ọmọ Ṣema, ọmọ Joeli.

Wọ́n tí ń gbé Aroeri àní títí dé Nebo àti Baali-Meoni. Àti níhà àríwá, o tẹ̀dó lọ títí dé àtiwọ aginjù láti odò Eufurate; nítorí tí ẹran ọ̀sìn wọn pọ̀ sí i ní ilẹ̀ Gileadi.

10 Àti ní ọjọ́ Saulu, wọ́n bá àwọn ọmọ Hagari jagun, ẹni tí ó ṣubú nípa ọwọ́ wọn; wọ́n sì ń gbé inú àgọ́ wọn ní gbogbo ilẹ̀ àríwá Gileadi.

Ìdílé Gadi

11 Àti àwọn ọmọ Gadi ń gbé lékè wọn, ní ilẹ̀ Baṣani títí dé Saleka:

12 Joeli jẹ́ olórí, Ṣafamu ìran ọmọ, Janai, àti Ṣafati ni Baṣani,

13 Àti àwọn arákùnrin wọn ti ilẹ̀ àwọn baba wọn ní:

Mikaeli, Meṣullamu Ṣeba, Jorai, Jaka, Sia àti Eberi méje.

14 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Abihaili, ọmọ Huri, ọmọ Jeroa, ọmọ Gileadi, ọmọ Mikaeli, ọmọ Jeṣiṣai, ọmọ Jado ọmọ Busi.

15 Ahi, ọmọ Adbeeli, ọmọ Guni, olórí ilé àwọn baba wọn.

16 Wọ́n sì ń gbé Gileadi ní Baṣani àti nínú àwọn ìlú rẹ̀, àti nínú gbogbo ìgbèríko Ṣaroni, ní agbègbè wọn.

17 Gbogbo wọ̀nyí ni a kà nípa ìtàn ìdílé, ní ọjọ́ Jotamu ọba Juda, àti ní ọjọ́ Jeroboamu ọba Israẹli.

18 Àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase, nínú àwọn ọkùnrin alágbára tí wọ́n ń gbé asà àti idà, tí wọ́n sì ń fi ọrun tafà, tí wọ́n sì mòye ogun, jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ènìyàn ó lé ẹgbẹ̀rìnlélógún dín ogójì, tí ó jáde lọ sí ogún náà. 19 Wọ́n sì bá àwọn ọmọ Hagari jagun, pẹ̀lú Jeturi, àti Nafiṣi àti Nadabu. 20 Nígbà tí wọ́n sì rí ìrànlọ́wọ́ gbà si, a sì fi àwọn ọmọ Hagari lé wọn lọ́wọ́, àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú wọn; nítorí tiwọn ké pe Ọlọ́run ní ogun náà, òun sì gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wọn; nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀ wọn lé e. 21 Wọ́n sì kó ẹran ọ̀sìn wọn lọ; ìbákasẹ ẹgbàá-mẹ́dọ́gbọ̀n àti àgùntàn ọ̀kẹ́ méjìlá ó lé ẹgbàárùn-ún, àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹgbàá, àti ènìyàn ọ̀kẹ́ márùn-ún. 22 Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó ṣubú tí a pa, nítorí láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ni ogun náà, wọ́n sì jókòó ní ipò wọn títí di ìgbà ìkólọ sí ìgbèkùn.

Ààbọ̀ Ẹ̀yà Manase

23 Àwọn ọmọkùnrin ààbọ̀ ẹ̀yà Manase ń gbé ní ilẹ̀ náà: wọ́n bí sí i láti Baṣani títí dé Baali-Hermoni, àti Seniri àti títí dé òkè Hermoni.

24 Wọ̀nyí sì ni àwọn olórí ilé àwọn baba wọn. Eferi, Iṣi, Elieli, Asrieli, Jeremiah, Hodafiah àti Jahdieli àwọn alágbára akọni ọkùnrin, ọkùnrin olókìkí, àti olórí ilé àwọn baba wọn. 25 Wọ́n sì ṣẹ̀ sí Ọlọ́run àwọn baba wọn, wọ́n sì ṣe àgbèrè tọ àwọn ọlọ́run ènìyàn ilẹ̀ náà lẹ́yìn, tí Ọlọ́run ti parun ní iwájú wọn. 26 Nítorí náà Ọlọ́run Israẹli ru ẹ̀mí Pulu ọba Asiria sókè (ẹ̀mí Tiglat-Pileseri ọba Asiria), ó si kó wọn lọ, àní àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase lọ sí ìgbèkùn. Ó sì kó wọn wá sí Hala, àti Habori, àti Harani, àti sí etí odò Gosani; títí dí òní yìí.

Reuben

The sons of Reuben(A) the firstborn of Israel (he was the firstborn, but when he defiled his father’s marriage bed,(B) his rights as firstborn were given to the sons of Joseph(C) son of Israel;(D) so he could not be listed in the genealogical record in accordance with his birthright,(E) and though Judah(F) was the strongest of his brothers and a ruler(G) came from him, the rights of the firstborn(H) belonged to Joseph)— the sons of Reuben(I) the firstborn of Israel:

Hanok, Pallu,(J) Hezron(K) and Karmi.

The descendants of Joel:

Shemaiah his son, Gog his son,

Shimei his son, Micah his son,

Reaiah his son, Baal his son,

and Beerah his son, whom Tiglath-Pileser[a](L) king of Assyria took into exile. Beerah was a leader of the Reubenites.

Their relatives by clans,(M) listed according to their genealogical records:

Jeiel the chief, Zechariah, and Bela son of Azaz, the son of Shema, the son of Joel. They settled in the area from Aroer(N) to Nebo(O) and Baal Meon.(P) To the east they occupied the land up to the edge of the desert that extends to the Euphrates(Q) River, because their livestock had increased in Gilead.(R)

10 During Saul’s reign they waged war against the Hagrites(S), who were defeated at their hands; they occupied the dwellings of the Hagrites throughout the entire region east of Gilead.

Gad

11 The Gadites(T) lived next to them in Bashan, as far as Salekah:(U)

12 Joel was the chief, Shapham the second, then Janai and Shaphat, in Bashan.

13 Their relatives, by families, were:

Michael, Meshullam, Sheba, Jorai, Jakan, Zia and Eber—seven in all.

14 These were the sons of Abihail son of Huri, the son of Jaroah, the son of Gilead, the son of Michael, the son of Jeshishai, the son of Jahdo, the son of Buz.

15 Ahi son of Abdiel, the son of Guni, was head of their family.

16 The Gadites lived in Gilead, in Bashan and its outlying villages, and on all the pasturelands of Sharon as far as they extended.

17 All these were entered in the genealogical records during the reigns of Jotham(V) king of Judah and Jeroboam(W) king of Israel.

18 The Reubenites, the Gadites and the half-tribe of Manasseh had 44,760 men ready for military service(X)—able-bodied men who could handle shield and sword, who could use a bow, and who were trained for battle. 19 They waged war against the Hagrites, Jetur,(Y) Naphish and Nodab. 20 They were helped(Z) in fighting them, and God delivered the Hagrites and all their allies into their hands, because they cried(AA) out to him during the battle. He answered their prayers, because they trusted(AB) in him. 21 They seized the livestock of the Hagrites—fifty thousand camels, two hundred fifty thousand sheep and two thousand donkeys. They also took one hundred thousand people captive, 22 and many others fell slain, because the battle(AC) was God’s. And they occupied the land until the exile.(AD)

The Half-Tribe of Manasseh

23 The people of the half-tribe of Manasseh(AE) were numerous; they settled in the land from Bashan to Baal Hermon, that is, to Senir (Mount Hermon).(AF)

24 These were the heads of their families: Epher, Ishi, Eliel, Azriel, Jeremiah, Hodaviah and Jahdiel. They were brave warriors, famous men, and heads of their families. 25 But they were unfaithful(AG) to the God of their ancestors and prostituted(AH) themselves to the gods of the peoples of the land, whom God had destroyed before them. 26 So the God of Israel stirred up the spirit(AI) of Pul(AJ) king of Assyria (that is, Tiglath-Pileser(AK) king of Assyria), who took the Reubenites, the Gadites and the half-tribe of Manasseh into exile. He took them to Halah,(AL) Habor, Hara and the river of Gozan, where they are to this day.

Footnotes

  1. 1 Chronicles 5:6 Hebrew Tilgath-Pilneser, a variant of Tiglath-Pileser; also in verse 26